< Mark 13 >

1 Bí Jesu ti ń jáde láti inú tẹmpili ní ọjọ́ náà, ọ̀kan nínú ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sọ fún un pé, “Olùkọ́, wo ilé ńlá tí ó dára wọ̀nyí. Sì wo òkúta tí a ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ lára àwọn ògiri ilé náà.”
ⲁ̅ⲟⲩⲟϩ ⲉϥⲛⲏⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⲡⲓⲉⲣⲫⲉⲓ ⲡⲉϫⲉ ⲟⲩⲁⲓ ⲛⲁϥ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⲛⲉϥⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ ϫⲉ ⳿ⲫⲣⲉϥϯ⳿ⲥⲃⲱ ⳿ⲭⲛⲁⲩ ϫⲉ ϩⲁⲛⲁϣ ⳿ⲛⲣⲏϯ ⲛⲉ ⲛⲁⲓ⳿ⲱⲛⲓ ⲟⲩⲟϩ ϩⲁⲛⲕⲱⲧ ⳿ⲛⲁϣ ⳿ⲛⲣⲏϯ.
2 Jesu dáhùn pé, “Ìwọ rí ilé ńlá wọ̀nyí? Kì yóò sí òkúta kan tí a ó fi sílẹ̀ lórí èkejì tí a kì yóò wó lulẹ̀.”
ⲃ̅ⲟⲩⲟϩ ⲡⲉϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲛⲁϥ ϫⲉ ⳿ⲭⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲛⲁⲓⲛⲓϣϯ ⳿ⲛ⳿ⲱⲛⲓ ⳿ⲛⲛⲟⲩⲭⲁ ⲟⲩ⳿ⲱⲛⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲟⲩ⳿ⲱⲛⲓ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲙⲁ ⳿ⲛⲥⲉⲛⲁⲃⲟⲗϥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲁⲛ.
3 Bí Jesu si ti jókòó lórí òkè olifi tí ó kọjú sí tẹmpili, Peteru, Jakọbu, Johanu àti Anderu wà pẹ̀lú rẹ̀ níbẹ̀, wọ́n bi í léèrè ni ìkọ̀kọ̀ pé,
ⲅ̅ⲟⲩⲟϩ ⲉϥϩⲉⲙⲥⲓ ϩⲓϫⲉⲛ ⲡⲓⲧⲱⲟⲩ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓϫⲱⲓⲧ ⳿ⲙⲡⲉ⳿ⲙⲑⲟ ⳿ⲙⲡⲓⲉⲣⲫⲉⲓ ⲁⲩϣⲉⲛϥ ⳿ⲛⲥⲁ ⳿ⲡⲥⲁ ⳿ⲛϫⲉ Ⲡⲉⲧⲣⲟⲥ ⲛⲉⲙ Ⲓⲁⲕⲱⲃⲟⲥ ⲛⲉⲙ Ⲓⲱⲁⲛⲛⲏⲥ ⲛⲉⲙ Ⲁⲛ⳿ⲇⲣⲉⲁⲥ
4 “Sọ fún wa, nígbà wo ni nǹkan wọ̀nyí yóò ṣẹlẹ̀ sí tẹmpili náà? Kí ni yóò sì jẹ́ àmì nígbà tí gbogbo nǹkan wọ̀nyí yóò ṣẹ?”
ⲇ̅ϫⲉ ⲁϫⲟⲥ ⲛⲁⲛ ϫⲉ ⳿ⲁⲣⲉ ⲛⲁⲓ ⲛⲁϣⲱⲡⲓ ⳿ⲛ⳿ⲑⲛⲁⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲟⲩ ⲡⲉ ⲡⲓⲙⲏⲓⲛⲓ ⳿ⲁⲣⲉϣⲁⲛ ⲛⲁⲓ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⲛⲟⲩ⳿ⲓ ⳿ⲉϫⲱⲕ ⳿ⲉⲃⲟⲗ.
5 Jesu kìlọ̀ fún wọn pé, “Ẹ má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni tàn yín.
ⲉ̅Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲇⲉ ⲁϥⲉⲣϩⲏⲧⲥ ⳿ⲛϫⲟⲥ ϫⲉ ⳿ⲁⲛⲁⲩ ⳿ⲙⲡⲉⲛ⳿ⲑⲣⲉ ⳿ϩⲗⲓ ⲥⲉⲣⲉⲙ ⲑⲏⲛⲟⲩ.
6 Nítorí pé ọ̀pọ̀lọpọ̀ yóò wá ní orúkọ mi, wọn yóò wí pé, ‘Èmi ni Kristi,’ wọn yóò tan ọ̀pọ̀ ènìyàn jẹ.
ⲋ̅ⲟⲩⲟⲛ ⲟⲩⲙⲏϣ ⲅⲁⲣ ⲛⲁⲓ ϧⲉⲛ ⲡⲁⲣⲁⲛ ⲉⲩϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲡⲉ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ⲟⲩⲟϩ ⲥⲉⲛⲁⲥⲉⲣⲉⲙ ⲟⲩⲙⲏϣ.
7 Nígbà tí ẹ̀yin bá ń gbọ́ ìró ogun àti ìdágìrì ogun, kí ẹ̀yin má ṣe jáyà, nítorí irú nǹkan wọ̀nyí kò le ṣe kí ó má ṣẹlẹ̀, ṣùgbọ́n òpin náà kì í ṣe ìgbà yìí.
ⲍ̅ϩⲟⲧⲁⲛ ⲇⲉ ⳿ⲁⲣⲉⲧⲉⲛϣⲁⲛⲥⲱⲧⲉⲙ ⳿ⲉϩⲁⲛⲡⲟⲗⲉⲙⲟⲥ ⲛⲉⲙ ϩⲁⲛ⳿ⲥⲙⲏ ⳿ⲙⲡⲟⲗⲉⲙⲟⲥ ⳿ⲙⲡⲉⲣ⳿ϣⲑⲟⲣⲧⲉⲣ ϩⲱϯ ⲡⲉ ⳿ⲛⲧⲟⲩϣⲱⲡⲓ ⲁⲗⲗⲁ ⳿ⲙⲡⲁⲧⲉϥ⳿ⲓ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲓϫⲱⲕ.
8 Orílẹ̀-èdè yóò dìde sí orílẹ̀-èdè, àti ìjọba sí ìjọba ilẹ̀ yóò máa jì ní ibi púpọ̀. Ìyàn yóò sì wà níbi gbogbo. Gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni ìbẹ̀rẹ̀ ìpọ́njú tí ń bọ̀ níwájú.
ⲏ̅ⲉϥ⳿ⲉⲧⲱⲛϥ ⲅⲁⲣ ⳿ⲛϫⲉ ⲟⲩⲉⲑⲛⲟⲥ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲟⲩⲉⲑⲛⲟⲥ ⲟⲩⲟϩ ⲟⲩⲙⲉⲧⲟⲩⲣⲟ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲟⲩⲙⲉⲧⲟⲩⲣⲟ ⲉⲩ⳿ⲉϣⲱⲡⲓ ⳿ⲛϫⲉ ϩⲁⲛⲙⲟⲛⲙⲉⲛ ⲕⲁⲧⲁ ⲙⲁ ⲉⲩ⳿ⲉϣⲱⲡⲓ ⳿ⲛϫⲉ ϩⲁⲛ⳿ϩⲃⲱⲛ ϩⲏ⳿ⲛⲛⲓⲛⲁⲕϩⲓ ⲛⲉ ⲛⲁⲓ.
9 “Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn nǹkan wọ̀nyí bá bẹ̀rẹ̀ sí i ṣẹlẹ̀, ẹ kíyèsára! Nítorí ẹ̀yin yóò wà nínú ewu. Wọn yóò fà yín lọ ilé ẹjọ́ gbogbo. Wọn yóò fi ìyà jẹ yín nínú Sinagọgu wọn. Àwọn ènìyàn yóò fẹ̀sùn kàn yín níwájú àwọn baálẹ̀ àti níwájú àwọn ọba nítorí orúkọ mi, fún ẹ̀rí fún wọn.
ⲑ̅⳿ⲁⲛⲁⲩ ⲇⲉ ⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲉⲣⲱⲧⲉⲛ ⲥⲉⲛⲁϯ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⳿ⲉϩⲁⲛⲙⲁ⳿ⲛϯϩⲁⲡ ⲟⲩⲟϩ ϧⲉⲛ ⲛⲓⲥⲩⲛⲁⲅⲱⲅⲏ ⲥⲉⲛⲁϩⲓⲟⲩ⳿ⲓ ⳿ⲉⲣⲱⲧⲉⲛ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲧⲟⲩⲧⲁϩⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲉⲣⲁⲧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲛⲁϩⲣⲉⲛ ϩⲁⲛϩⲏⲅⲉⲙⲱⲛ ⲛⲉⲙ ϩⲁⲛⲟⲩⲣⲱⲟⲩ ⲉⲑⲃⲏⲧ ⲉⲩⲙⲉⲧⲙⲉⲑⲣⲉ ⲛⲱⲟⲩ ⲛⲉⲙ ⲛⲓⲉⲑⲛⲟⲥ ⲧⲏⲣⲟⲩ.
10 Nítorí pé ẹ gbọdọ̀ kọ́kọ́ wàásù ìyìnrere náà fún gbogbo orílẹ̀-èdè kí òpin tó dé.
ⲓ̅ϩⲱϯ ⳿ⲛϣⲟⲣⲡ ⳿ⲛⲧⲟⲩϩⲓⲱⲓϣ ⳿ⲙⲡⲓⲉⲩⲁⲅⲅⲉⲗⲓⲟⲛ.
11 Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n bá ń fà yín lọ, tí wọ́n bá sì ń fi yín lé wọn lọ́wọ́, ẹ má ṣe ṣàníyàn ṣáájú ohun tí ẹ ó sọ. Ṣùgbọ́n ohun tí bá fi fún yín ní wákàtí náà, òun ni kí ẹ̀yin kí ó wí. Nítorí kì í ṣe ẹ̀yin ni ó ń wí, bí kò ṣe Ẹ̀mí Mímọ́.
ⲓ̅ⲁ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉϣⲱⲡ ⳿ⲛⲧⲟⲩⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲉⲩϯ ⳿ⲙⲙⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲙⲡⲉⲣⲉⲣϣⲟⲣⲡ ⳿ⲛϥⲓⲣⲱⲟⲩϣ ϫⲉ ⲟⲩ ⲡⲉⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁⲥⲁϫⲓ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲁⲗⲗⲁ ⲡⲉⲧⲟⲩⲛⲁⲧⲏⲓϥ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϧⲉⲛ ϯⲟⲩⲛⲟⲩ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲫⲁⲓ ⲡⲉⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁⲥⲁϫⲓ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ⲅⲁⲣ ⲁⲛ ⲡⲉⲑⲛⲁⲥⲁϫⲓ ⲁⲗⲗⲁ ⲡⲠⲓⲡ͞ⲛⲁ̅ ⲉⲑⲟⲩⲁⲃ ⲡⲉ.
12 “Arákùnrin yóò máa fi ẹ̀sùn kan arákùnrin rẹ̀, tí yóò sì yọrí sí ikú. Baba yóò máa ṣe ikú pa ọmọ rẹ̀. Àwọn ọmọ yóò máa dìtẹ̀ sí òbí wọn. Àní, àwọn ọmọ pẹ̀lú yóò máa ṣe ikú pa òbí wọn.
ⲓ̅ⲃ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲣⲉ ⲟⲩⲥⲟⲛ ϯ ⳿ⲛⲟⲩⲥⲟⲛ ⳿ⲉ⳿ⲫⲙⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲣⲉ ⲟⲩⲓⲱⲧ ⲉϥ⳿ⲉϯ ⳿ⲛⲟⲩϣⲏⲣⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲥⲉⲛⲁⲧⲱⲟⲩⲛⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ ϩⲁⲛϣⲏⲣⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ϩⲁⲛⲓⲟϯ ⲟⲩⲟϩ ⲥⲉⲛⲁϧⲟⲑⲃⲟⲩ.
13 Àwọn ènìyàn yóò kórìíra yín nítorí tí ẹ jẹ́ tèmi. Ṣùgbọ́n ẹni tó bá fi ara da ìyà títí dé òpin tí kò sì kọ̀ mí sílẹ̀ òun ni yóò rí ìgbàlà.
ⲓ̅ⲅ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲣⲉⲧⲉⲛ⳿ⲉϣⲱⲡⲓ ⲉⲩⲙⲟⲥϯ ⳿ⲙⲙⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲛϫⲉ ⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲉⲑⲃⲉ ⲡⲁⲣⲁⲛ ⲫⲏ ⲇⲉ ⲉⲑⲛⲁ⳿ⲁⲙⲟⲛⲓ ⳿ⲛⲧⲟⲧϥ ϣⲁ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲫⲁⲓ ⲡⲉ ⲫⲏⲉⲑⲛⲁⲛⲟϩⲉⲙ.
14 “Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹ̀yin bá rí ìríra ìsọdahoro, tí ó dúró níbí tí kò yẹ (ẹnikẹ́ni tí ó bá kà á kí ó yé e), nígbà náà ni kí àwọn tí ń bẹ ni Judea sálọ sí orí òkè.
ⲓ̅ⲇ̅⳿ⲉϣⲱⲡ ⲇⲉ ⳿ⲛⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲡⲓⲥⲱϥ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓϣⲱϥ ⲉϥ⳿ⲟϩⲓ ⳿ⲉⲣⲁⲧϥ ⳿ⲙⲡⲓⲙⲁ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲥϣⲉ ⲁⲛ ⲫⲏⲉⲧⲱϣ ⲙⲁⲣⲉϥⲕⲁϯ ⲧⲟⲧⲉ ⲛⲏⲉⲧⲭⲏ ϧⲉⲛϯⲒⲟⲩⲇⲉ⳿ⲁ ⲙⲁⲣⲟⲩⲫⲱⲧ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲛⲓⲧⲱⲟⲩ.
15 Kí ẹni ti ń bẹ lórí ilé má ṣe sọ̀kalẹ̀ lọ sínú ilé, bẹ́ẹ̀ ni kí ó má sì ṣe wọ inú rẹ̀, láti mú ohunkóhun jáde nínú ilé rẹ̀.
ⲓ̅ⲉ̅ⲫⲏⲉⲧϩⲓϫⲉⲛ ⳿ⲡϫ⳿ⲉⲛⲉⲫⲱⲣ ⳿ⲙⲡⲉⲛ⳿ⲑⲣⲉϥ⳿Ⲓ ⳿ⲉ⳿ϧⲣⲏⲓ ⲟⲩⲇⲉ ⳿ⲙⲡⲉⲛ⳿ⲑⲣⲉϥϣⲉ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉⲉⲗ ⳿ϩⲗⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⲡⲉϥⲏⲓ.
16 Kí ẹni tí ó wà lóko má ṣe padà sẹ́yìn láti wá mú aṣọ rẹ̀.
ⲓ̅ⲋ̅ⲟⲩⲟϩ ⲫⲏⲉⲧϧⲉⲛ ⳿ⲧⲕⲟⲓ ⳿ⲙⲡⲉⲛ⳿ⲑⲣⲉϥ⳿Ⲓ ⳿ⲉⲫⲁϩⲟⲩ ⳿ⲉⲉⲗ ⲡⲉϥ⳿ϩⲃⲟⲥ.
17 Ègbé ní fún àwọn tí ó lóyún, àti fún obìnrin tí ń fún ọ́mọ lọ́mú ní ọjọ́ wọ̀nyí.
ⲓ̅ⲍ̅ⲟⲩⲟⲓ ⲇⲉ ⳿ⲛⲛⲏ⳿ⲉⲧⲉⲙⲃⲟⲕⲓ ⲛⲉⲙ ⲛⲏⲉⲧϯϭⲓ ϧⲉⲛ ⲛⲓ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲁⲩ.
18 Kí ẹ sì máa gbàdúrà pé èyí ṣẹlẹ̀ ní àkókò òtútù.
ⲓ̅ⲏ̅ⲁⲣⲓ⳿ⲡⲣⲟⲥⲉⲩⲭⲉⲥⲑⲉ ⲇⲉ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉϥ⳿ϣⲧⲉⲙϣⲱⲡⲓ ϧⲉⲛ ⲧ⳿ⲫⲣⲱ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲉⲧⲉⲛⲫⲱⲧ.
19 Nítorí ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì yóò jẹ́ àkókò ìpọ́njú, irú èyí tí kò ì ṣẹlẹ̀ láti ìbẹ̀rẹ̀ ẹ̀dá Ọlọ́run. Irú rẹ̀ kò sì ni ṣẹlẹ̀ mọ́.
ⲓ̅ⲑ̅ⲉⲩ⳿ⲉϣⲱⲡⲓ ⲅⲁⲣ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲓ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲁⲩ ϩⲟϫϩⲉϫ ⳿ⲙⲡⲉ ⲟⲩⲟⲛ ϣⲱⲡⲓ ⳿ⲙⲡⲉϥⲣⲏϯ ⲓⲥϫⲉⲛ ϩⲏ ⳿ⲙⲡⲓⲥⲱⲛⲧ ⳿ⲉⲧⲁϥⲥⲟⲛⲧϥ ⳿ⲛϫⲉ ⲫϯϣⲁ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉϯⲛⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲛⲉ ⲟⲩⲟⲛ ϣⲱⲡⲓ ⲟⲛ.
20 “Àfi tí Olúwa bá gé àkókò ìjìyà náà kúrú, ẹyọ ẹ̀mí kan ní ayé kì yóò là. Ṣùgbọ́n nítorí àwọn tí Ọlọ́run yàn, ni yóò ṣe dín àwọn ọjọ́ náà kù.
ⲕ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿⳿ⲉⲛⲉ ⳿ⲙⲡⲉ Ⲡ⳪ ⲉⲑⲣⲉ ⲛⲓ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲉⲣⲕⲟⲩϫⲓ ⲛⲁⲩⲛⲁⲛⲟϩⲉⲙ ⲁⲛ ⲡⲉ ⳿ⲛϫⲉ ⲥⲁⲣⲝ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲁⲗⲗⲁ ⲉⲑⲃⲉ ⲛⲓⲥⲱⲧⲡ ⳿ⲉⲧⲁϥⲥⲟⲧⲡⲟⲩ ⲁϥϫⲉϫⲉⲃ ⲛⲓ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ.
21 Nígbà náà, bí ẹnikẹ́ni bá sọ fún un yín pé, ‘Ẹ wò ó, Kristi wa níbi yìí!’ tàbí, sọ fún un yín pé, ‘Ẹ wò ó, ó wà lọ́hùn ún nì!’ Ẹ má ṣe gbà wọ́n gbọ́.
ⲕ̅ⲁ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉϣⲱⲡ ⳿ⲛⲧⲉ ⲟⲩⲁⲓ ϫⲟⲥ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϫⲉ ⲓⲥ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ϩⲁ⳿ⲙⲛⲁⲓ ⲓⲉ ϩⲁ⳿ⲙⲛⲏ⳿ⲙⲡⲉⲣⲛⲁϩϯ.
22 Nítorí àwọn èké Kristi àti àwọn wòlíì èké ni yóò wá, wọn yóò sì fi iṣẹ́ ìyanu tí yóò tan ènìyàn jẹ hàn. Bí ó bá ṣe é ṣe, wọn yóò tan àwọn àyànfẹ́ pàápàá jẹ.
ⲕ̅ⲃ̅ⲉⲩ⳿ⲉⲧⲱⲟⲩⲛⲟⲩ ⲅⲁⲣ ⳿ⲛϫⲉ ϩⲁⲛⲭ̅ⲥ̅ ⳿ⲛⲛⲟⲩϫ ⲛⲉⲙ ϩⲁⲛ⳿ⲡⲣⲟⲫⲏⲧⲏⲥ ⳿ⲛⲛⲟⲩϫ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲟⲩϯ ⳿ⲛϩⲁⲛⲙⲏⲓⲛⲓ ⲛⲉⲙ ϩⲁⲛ⳿ϣⲫⲏⲣⲓ ⲉ⳿ⲡϫⲓⲛⲥⲱⲣⲉⲙ ⲁⲩϣⲁⲛ⳿ϣϫⲉⲙϫⲟⲙ ⳿ⲛⲛⲓⲕⲉⲥⲱⲧⲡ.
23 Nítorí náà, ẹ ṣọ́ra. Mo ti kìlọ̀ fún un yín ṣáájú tó!
ⲕ̅ⲅ̅⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ⲇⲉ ⳿ⲁⲛⲁⲩ ϫⲉ ⲁⲓⲉⲣϣⲟⲣⲡ ⳿ⲛϫⲉ ϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ.
24 “Ṣùgbọ́n ni ọjọ́ wọ̀nyí lẹ́yìn ìpọ́njú tí mo sọ yìí, “‘oòrùn yóò ṣókùnkùn, òṣùpá kò ní tan ìmọ́lẹ̀ rẹ̀.
ⲕ̅ⲇ̅ⲁⲗⲗⲁ ϧⲉⲛ ⲛⲓ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲙⲉⲛⲉⲛⲥⲁ ⳿ⲡϩⲟϫϩⲉϫ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲡⲓⲣⲏⲉϥ⳿ⲉⲉⲣⲭ ⲁⲕⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲡⲓⲓⲟϩ ⳿ⲛⲛⲉϥϯ ⳿ⲙⲡⲉϥⲟⲩⲱⲓⲛⲓ.
25 Àwọn ìràwọ̀ pẹ̀lú yóò já lulẹ̀ láti ojú ọ̀run, àti agbára tí ń bẹ ní ọ̀run ni a ó sì mì tìtì.’
ⲕ̅ⲉ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲓⲥⲓⲟⲩ ⲉⲩ⳿ⲉϣⲱⲡⲓ ⲉⲩϩⲓⲱⲟⲩⲧ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⳿ⲧⲫⲉ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲓϫⲟⲙ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓⲫⲏⲟⲩ⳿ⲓ ⲉⲩ⳿ⲉⲕⲓⲙ.
26 “Nígbà náà ni gbogbo ayé yóò sì rí i tí èmi Ọmọ Ènìyàn yóò máa bọ̀ wá láti inú àwọsánmọ̀ pẹ̀lú agbára àti ògo ńlá.
ⲕ̅ⲋ̅ⲟⲩⲟϩ ⲧⲟⲧⲉ ⲉⲩ⳿ⲉⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲠ̇ϣⲏⲣⲓ ⳿ⲙⲪ̇ⲣⲱⲙⲓ ⲉϥⲛⲏⲟⲩ ϧⲉⲛ ϩⲁⲛϭⲏⲡⲓ ⲛⲉⲙ ⲟⲩⲛⲓϣϯ ⳿ⲛϫⲟⲙ ⲛⲉⲙ ⲟⲩⲱⲟⲩ.
27 Nígbà náà ni yóò sì rán àwọn angẹli rẹ̀ láti kó àwọn àyànfẹ́ ní gbogbo ayé jọ láti orígun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ayé láti ìkangun ayé títí dé ìkangun ọ̀run.
ⲕ̅ⲍ̅ⲧⲟⲧⲉ ⳿ϥⲛⲁⲟⲩⲱⲣⲡ ⳿ⲛⲛⲉϥⲁⲅⲅⲉⲗⲟⲥ ⲟⲩⲟϩ ⳿ϥⲛⲁⲑⲱⲟⲩϯ ⳿ⲛⲛⲉϥⲥⲱⲧⲡ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⲡⲓ⳿ϥⲧⲟⲩ ⲑⲏⲟⲩ ⲓⲥϫⲉⲛ ⲁⲩⲣⲏϫϥ ⳿ⲙ⳿ⲡⲕⲁϩⲓ ϣⲁ ⲁⲩⲣⲏϫⲥ ⳿ⲛ⳿ⲧⲫⲉ.
28 “Nísinsin yìí, ẹ kọ́ òwe lára igi ọ̀pọ̀tọ́, nígbà tí ẹ̀ka rẹ bá ń yọ tuntun, tí ó bá sì ń rú ewé, èyí fihàn pé àkókò ẹ̀rùn ti dé.
ⲕ̅ⲏ̅⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲇⲉ ϧⲉⲛ ϯⲃⲱ ⳿ⲛⲕⲉⲛⲧⲉ ⳿ⲁⲣⲓ⳿ⲉⲙⲓ ⳿ⲉϯⲡⲁⲣⲟⲃⲟⲗⲏ⳿ⲉϣⲱⲡ ϩⲏⲇⲏ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲉⲥϫⲁⲗ ϭⲛⲟⲛ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲉⲥϩⲓ ϫⲱⲃⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϣ⳿ⲁⲣⲉⲧⲉⲛ⳿ⲉⲙⲓ ϫⲉ ⳿ϥϧⲉⲛⲧ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲓϣⲱⲙ.
29 Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́, nígbà tí ẹ ba ri àwọn ohun wọ̀nyí ti n ṣẹlẹ̀, kí ẹ mọ̀ pé ó súnmọ́ etílé tán, bi ìgbà tí ó wà lẹ́yìn ìlẹ̀kùn.
ⲕ̅ⲑ̅ⲡⲁⲓⲣⲏϯ ⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲙ ϩⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲉϣⲱⲡ ⳿ⲁⲣⲉⲧⲉⲛϣⲀⲛⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲛⲁⲓ ⳿ⲉⲁⲩϣⲱⲡⲓ ⳿ⲁⲣⲓ⳿ⲉⲙⲓ ϫⲉ ⳿ϥϧⲱⲛⲧ ⳿ⲉⲛⲓⲣⲱⲟⲩ.
30 Lóòótọ́ ni mo wí fún un yín, ìran yìí kì yóò rékọjá títí a ó fi mú gbogbo nǹkan wọ̀nyí ṣẹ.
ⲗ̅⳿ⲁⲙⲏⲛ ϯϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϫⲉ ⳿ⲛⲛⲉ ⲧⲁⲓⲅ⳿ⲉⲛⲉ⳿ⲁ ⲥⲓⲛⲓ ϣⲁⲧⲉ ⲛⲁⲓ ⲧⲏⲣⲟⲩ ϣⲱⲡⲓ.
31 Ọ̀run àti ayé yóò kọjá lọ, ṣùgbọ́n àwọn ọ̀rọ̀ mi dúró dájú títí ayé àìnípẹ̀kun.
ⲗ̅ⲁ̅⳿ⲧⲫⲉ ⲛⲉⲙ ⲡⲓⲕⲁϩⲓ ⲥⲉⲛⲁⲥⲓⲛⲓ ⲛⲁⲥⲁϫⲓ ⲇⲉ ⳿ⲛⲛⲟⲩⲥⲓⲛⲓ.
32 “Ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí ó mọ ọjọ́ tàbí wákàtí tí nǹkan wọ̀nyí yóò ṣẹlẹ̀. Àwọn angẹli ọ̀run pàápàá kò mọ̀. Àní, èmi pẹ̀lú kò mọ̀ ọ́n, bí kò ṣe baba nìkan.
ⲗ̅ⲃ̅ⲉⲑⲃⲉ ⲡⲓ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⲇⲉ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲛⲉⲙ ϯⲟⲩⲛⲟⲩ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⳿ϩⲗⲓ ⳿ⲉⲙⲓ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ ⲟⲩⲇⲉ ⲁⲅⲅⲉⲗⲟⲥ ϧⲉⲛ ⳿ⲧⲫⲉ ⲟⲩⲇⲉ ⳿ⲡϣⲏⲣⲓ ⳿ⲉⲃⲏⲗ ⳿ⲉⲪ̇ⲓⲱⲧ.
33 Ẹ máa ṣọ́ra, ẹ dúró wámú, kí ẹ sì máa gbàdúrà, nítorí ẹ̀yin kò mọ ìgbà tí àkókò ná yóò dé.
ⲗ̅ⲅ̅ϫⲟⲩϣⲧ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲣⲱⲓⲥ ⳿ⲁⲣⲓ⳿ⲡⲣⲟⲥⲉⲩⲭⲉⲥⲑⲉ ⳿ⲛⲧⲉⲧⲉⲛⲥⲱⲟⲩⲛ ⲅⲁⲣ ⲁⲛ ϫⲉ ⳿ⲑⲛⲁⲩ ⲡⲉ ⲡⲓⲥⲏⲟⲩ.
34 Ó dà bí ọkùnrin kan tí ó lọ sí ìrìnàjò tí ó jìnnà rere, ẹni tí ó fi ilé rẹ̀ sílẹ̀, tí ó sì fi àṣẹ fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀, àti iṣẹ́ tí ẹnìkọ̀ọ̀kan yóò ṣe, ó sì fi àṣẹ fún ẹni tó dúró lẹ́nu-ọ̀nà láti máa ṣọ́nà.
ⲗ̅ⲇ̅⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⳿ⲛⲟⲩⲣⲱⲙⲓ ⳿ⲉⲁϥⲙⲟϣⲓ ⳿ⲉ⳿ⲡϣⲉⲙⲙⲟ ⳿ⲉⲁϥⲭⲱ ⳿ⲙⲡⲉϥⲏⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥϯ ⳿ⲛⲛⲉϥ⳿ⲉⲃⲓⲁⲓⲕ ⳿ⲙⲡⲓⲉⲣϣⲓϣⲓ ⳿ⲫⲟⲩⲁⲓ ⳿ⲫⲟⲩⲁⲓ ⳿ⲙⲡⲉϥϩⲱⲃ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥϩⲟⲛϩⲉⲛ ⳿ⲉⲧⲟⲧϥ ⳿ⲙⲡⲓⲉⲙⲛⲟⲩⲧ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉϥⲣⲱⲓⲥ.
35 “Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́, ẹ̀yin pẹ̀lú ní láti máa fi ìrètí ṣọ́nà, nítorí pé ẹ kò mọ àkókò tí baálé ilé yóò dé. Bóyá ní ìrọ̀lẹ́ ni o, tàbí ní ọ̀gànjọ́ òru, tàbí nígbà tí àkùkọ máa ń kọ, tàbí ní òwúrọ̀.
ⲗ̅ⲉ̅ⲣⲱⲓⲥ ⲟⲩⲛ ⳿ⲛⲧⲉⲧⲉⲛⲥⲱⲟⲩⲛ ⲅⲁⲣ ⲁⲛ ϫⲉ ⳿ⲁⲣⲉ Ⲡ⳪ ⳿ⲙⲡⲓⲏⲓ ⲛⲏⲟⲩ ⳿ⲛ⳿ⲑⲛⲁⲩ ⲓⲉ ϩⲁⲛⲁⲣⲟⲩϩⲓ ⲓⲉ ⳿ⲧⲫⲁϣⲓ ⳿ⲙⲡⲓ⳿ⲉϫⲱⲣϩ ⲓⲉ ⳿ⲉⲣⲉ ⲓ⳿ⲁⲗⲉⲕⲧⲱⲣ ⲙⲟⲩϯ ⲓⲉ ϩⲁⲛ⳿ⲁⲧⲟⲟⲩ⳿ⲓ.
36 Àti wí pé nígbà tí ó bá dé lójijì, kó má ṣe bá yín lójú oorun.
ⲗ̅ⲋ̅ⲙⲏⲡⲱⲥ ⳿ⲛⲧⲉϥ⳿ⲓ ⳿ⲛⲟⲩϩⲟϯ ϧⲉⲛ ⲟⲩϩⲟϯ ⳿ⲛⲧⲉϥϫⲉⲙ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⳿ⲉⲣⲉⲧ⳿ⲉⲛⲉⲛⲕⲟⲧ.
37 Ohun tí mo wí fún un yín, mo wí fun gbogbo ènìyàn: ‘Ẹ máa ṣọ́nà!’”
ⲗ̅ⲍ̅ⲡⲉϯϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϯϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲛⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲣⲱⲓⲥ.

< Mark 13 >