< Mark 11 >
1 Bí wọ́n ti súnmọ́ Betfage àti Betani ní ẹ̀yìn odi ìlú Jerusalẹmu, wọ́n dé orí òkè olifi. Jesu rán méjì nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ síwájú.
ⲁ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁϥϧⲱⲛⲧ ⳿ⲉⲒⲗ̅ⲏ̅ⲙ̅ ⲁϥ⳿ⲓ ⳿ⲉⲃⲏ ⲑⲫⲁⲅⲏⲛⲉⲙ Ⲃⲏⲑⲁⲛⲓ⳿ⲁ ϧⲁⲧⲉⲛ ⲡⲓⲧⲱⲟⲩ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓϫⲱⲓⲧ ⲁϥⲟⲩⲱⲣⲡ ⳿ⲛⲃ̅ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⲛⲉϥⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ
2 Ó pàṣẹ fún wọn pé, “Ẹ lọ sí abúlé tó wà lọ́hùn ún nì. Nígbà tí ẹ bá sì wọlé, ẹ̀yin yóò rí ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí a so mọ́lẹ̀ tí ẹnikẹ́ni kò ì tí i gùn rí. Ẹ tú u, kí ẹ sì mú wá sí ibi yìí.
ⲃ̅ⲟⲩⲟϩ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ⲙⲁϣⲉⲛⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲉⲡⲁⲓϯⲙⲓ ⲉⲧⲭⲏ ⳿ⲙⲡⲉⲧⲉⲛ⳿ⲙⲑⲟ ⲟⲩⲟϩ ⲥⲁⲧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⳿ⲉⲣⲉⲧⲉⲛⲛⲁϣⲉ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⳿ⲉⲣⲉⲧⲉⲛ⳿ⲉϫⲓⲙⲓ ⳿ⲛⲟⲩⲥⲏϫ ⲉϥⲥⲟⲛϩ ⲫⲁⲓ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲡⲁⲧⲉ ⳿ϩⲗⲓ ⳿ⲛⲣⲱⲙⲓ ⳿ⲁⲗⲏⲓ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⲙⲁϯⲟⲩⲱ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲁⲛⲓⲧϥ.
3 Bí ẹnikẹ́ni bá bi yín pé, ‘Kí ló dé tí ẹ fi ń ṣe èyí?’ Ẹ sọ fún un pé, ‘Olúwa ní í fi ṣe, yóò sì dá a padà síbí láìpẹ́.’”
ⲅ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉϣⲱⲡ ⳿ⲛⲧⲉ ⲟⲩⲁⲓ ϫⲟⲥ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϫⲉ ⲟⲩ ⲡⲉ ⲫⲁⲓ ⳿ⲉⲧⲉⲧⲉⲛ⳿⳿ⲓⲣⲓ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲁϫⲟⲥ ϫⲉ Ⲡ⳪ ⲡⲉⲧⲉⲣ⳿ⲭⲣⲓ⳿ⲁ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲟⲩⲟϩ ⲥⲁⲧⲟⲧϥ⳿ϥⲛⲁⲟⲩⲟⲣⲡϥ ⳿ⲙⲛⲁⲓ.
4 Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn méjì náà lọ bí ó ti rán wọn. Wọ́n rí ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà tí a so ní ẹnu-ọ̀nà lóde ní ìta gbangba, wọ́n sì tú u.
ⲇ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩϣⲉⲛⲱⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩϫⲓⲙⲓ ⳿ⲛⲟⲩⲥⲏϫ ⲉϥⲥⲟⲛϩ ϧⲁⲧⲉⲛ ⲟⲩⲣⲟ ⲥⲁⲃⲟⲗ ⳿ⲙⲡⲓϧⲓⲣ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩϯⲟⲩⲱ ⳿ⲙⲙⲟϥ.
5 Bí wọ́n ti ń tú u, díẹ̀ nínú àwọn tí ó dúró níbẹ̀ bi wọ́n léèrè pé, “Ki ni ẹyin n ṣe, tí ẹ̀yin fi ń tú ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ n nì?”
ⲉ̅ⲟⲩⲟϩ ϩⲁⲛⲟⲩⲟⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⲛⲏⲉⲧ⳿ⲟϩⲓ ⳿ⲉⲣⲁⲧⲟⲩ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲛⲁⲩϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ⲟⲩ ⲡⲉⲧⲉⲧⲉⲛ⳿⳿ⲓⲣⲓ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ ⳿ⲉⲣⲉⲧⲉⲛϯⲟⲩⲱ ⳿ⲙⲡⲓⲥⲏϫ.
6 Wọ́n sì wí fún wọn gẹ́gẹ́ bí Jesu ti ní kí wọ́n sọ, wọ́n sì jọ̀wọ́ wọn lọ́wọ́ lọ.
ⲋ̅⳿ⲛⲑⲱⲟⲩ ⲇⲉ ⲁⲩϫⲟⲥ ⲛⲱⲟⲩ ⲕⲁⲧⲁ⳿ⲫⲣⲏϯ ⳿ⲉⲧⲁϥϫⲟⲥ ⲛⲱⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩⲭⲁⲩ.
7 Wọ́n fa ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà tọ Jesu wá. Wọ́n tẹ́ aṣọ wọn sí ẹ̀yìn rẹ̀, òun sì jókòó lórí rẹ̀.
ⲍ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩ⳿ⲓⲛⲓ ⳿ⲙⲡⲓⲥⲏϫ ϩⲁ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩⲧⲁⲗⲉ ⳿ⲛⲟⲩ⳿ϩⲃⲱⲥ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥϩⲉⲙⲥⲓ ϩⲓϫⲱⲟⲩ.
8 Àwọn púpọ̀ tẹ́ aṣọ wọn sí ọ̀nà. Àwọn mìíràn ṣẹ́ ẹ̀ka igi, wọ́n sì fọ́n wọn sí ọ̀nà.
ⲏ̅ⲟⲩⲟϩ ϩⲁⲛⲙⲏϣ ⲁⲩⲫⲱⲣϣ ⳿ⲛⲛⲟⲩ⳿ϩⲃⲱⲥ ϩⲓ ⲡⲓⲙⲱⲓⲧ ϩⲁⲛⲕⲉⲭⲱⲟⲩⲛⲓ ⲇⲉ ⲁⲩⲕⲱⲣϫ ⳿ⲛϩⲁⲛϫⲁⲗ ⳿ⲛ⳿ϣϣⲏⲛ ϧⲉⲛ ⲛⲓⲓⲟϩⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩⲫⲱⲣϣ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ϩⲓ ⲡⲓⲙⲱⲓⲧ.
9 Àti àwọn tí ń lọ níwájú, àti àwọn tí ń bọ̀ lẹ́yìn, gbogbo wọn sì ń kígbe wí pé, “Hosana!” “Olùbùkún ni ẹni náà tí ó ń bọ̀ wà ní orúkọ Olúwa!”
ⲑ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲏ⳿ⲉⲛⲁⲩⲙⲟϣⲓ ϩⲓ⳿ⲧϩⲏ ⲛⲉⲙ ⲛⲏ⳿ⲉⲛⲁⲩⲙⲟϣⲓ ϩⲓⲫⲁϩⲟⲩ ⲛⲁⲩⲱϣ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϫⲉ ⳿ⲱⲥⲀⲛⲛⲁ ⳿ϥ⳿ⲥⲙⲁⲣⲱⲟⲩⲧ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲉⲑⲛⲏⲟⲩ ϧⲉⲛ ⳿ⲫⲣⲁⲛ ⳿ⲙⲠ⳪
10 “Olùbùkún ni fún ìjọba tí ń bọ̀ wá, ìjọba Dafidi, baba wa!” “Hosana lókè ọ̀run!”
ⲓ̅⳿ⲥ⳿ⲥⲙⲁⲣⲱⲟⲩⲧ ⳿ⲛϫⲉ ϯⲙⲉⲧⲟⲩⲣⲟ ⲉⲑⲛⲏⲟⲩ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲉⲛⲓⲱⲧ Ⲇⲁⲩⲓⲇ ⳿ⲱⲥⲀⲛⲛⲁ ϧⲉⲛ ⲛⲏⲉⲧϭⲟⲥⲓ.
11 Jesu wọ Jerusalẹmu ó sì lọ sí inú tẹmpili. Ó wo ohun gbogbo yíká fínní fínní. Ó sì kúrò níbẹ̀, nítorí pé ilẹ̀ ti ṣú. Ó padà lọ sí Betani pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ méjìlá.
ⲓ̅ⲁ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁϥ⳿ⲓ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉⲓⲗ̅ⲏ̅ⲙ̅ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉⲡⲓⲉⲣⲫⲉⲓ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁϥⲥⲟⲙⲥ ⳿ⲉ⳿ⲡⲧⲏⲣϥ ⳿ⲉⲧⲁ ⲣⲟⲩϩⲓ ϩⲏⲇⲏ ϣⲱⲡⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲟⲩⲟⲩⲛⲟⲩ ⲁϥ⳿ⲓ ⳿ⲉⲂⲏⲑⲁⲛⲓ⳿ⲁ ⲛⲉⲙ ⲡⲓⲓ̅ⲃ̅
12 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, bí wọ́n ti kúrò ní Betani, ebi ń pa Jesu.
ⲓ̅ⲃ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲡⲉϥⲣⲁⲥϯ ⳿ⲉⲧⲁⲩ⳿ⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ Ⲃⲏⲑⲁⲛⲓ⳿ⲁ ⲁϥ⳿ϩⲕⲟ.
13 Ó rí igi ọ̀pọ̀tọ́ kan lọ́ọ̀ọ́kán tí ewé kún orí rẹ̀. Nígbà náà, ó lọ sí ìdí rẹ̀ láti wò ó bóyá ó léso tàbí kò léso. Nígbà tí ó dé ibẹ̀, ewé lásán ni ó rí, kò rí èso lórí rẹ̀. Nítorí pé àkókò náà kì í ṣe àkókò tí igi ọ̀pọ̀tọ́ máa ń so.
ⲓ̅ⲅ̅⳿ⲉⲧⲁϥⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲟⲩⲃⲱ ⳿ⲛⲕⲉⲛⲧⲉ ϩⲓⲫⲟⲩⲉⲓ ⳿ⲉⲟⲩⲟⲛ ϩⲁⲛϫⲱⲃⲓ ϩⲓⲱⲧⲥ ⲁϥ⳿ⲓ ϫⲉ ϩⲁⲣⲁ ⳿ϥⲛⲁϫⲉⲙ ⳿ϩⲗⲓ ϩⲓⲱⲧⲥ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁϥ⳿ⲓ ⳿ⲉϫⲱⲥ ⳿ⲙⲡⲉϥϫⲉⲙ ⳿ϩⲗⲓ ⳿ⲉⲃⲏⲗ ⳿ⲉϩⲁⲛϫⲱⲃⲓ ⲛⲉ ⳿ⲡⲥⲏⲟⲩ ⲅⲁⲣ ⳿ⲛⲕⲉⲛⲧⲉ ⲁⲛ ⲡⲉ.
14 Lẹ́yìn náà, Jesu pàṣẹ fún igi náà pé, “Kí ẹnikẹ́ni má ṣe jẹ èso lórí rẹ mọ́ títí láé.” Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ gbọ́ nígbà tí ó wí bẹ́ẹ̀. (aiōn )
ⲓ̅ⲇ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁϥ⳿ⲉⲣⲟⲩ⳿ⲱ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲁⲥ ϫⲉ ⳿ⲛⲛⲉ ⳿ϩⲗⲓ ϫⲉⲙ ⲟⲩⲧⲁϩ ϩⲓⲱϯ ϣⲁ ⳿⳿ⲉⲛⲉϩ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁⲩⲥⲱⲧⲉⲙ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲉϥⲙⲁⲑⲏⲧⲏ. (aiōn )
15 Nígbà ti wọ́n padà sí Jerusalẹmu, ó wọ inú tẹmpili. Ó bẹ̀rẹ̀ sí nílé àwọn oníṣòwò àti àwọn oníbàárà wọn síta. Ó ti tábìlì àwọn tí ń pààrọ̀ owó nínú tẹmpili ṣubú. Bákan náà ni ó ti ìjókòó àwọn tí ń ta ẹyẹlé lulẹ̀.
ⲓ̅ⲉ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩ⳿ⲓ ⳿ⲉⲓⲗ̅ⲏ̅ⲙ̅ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁϥ⳿ⲓ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉⲡⲓⲉⲣⲫⲉⲓ ⲁϥⲉⲣϩⲏⲧⲥ ⳿ⲛϩⲓⲟⲩ⳿ⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛⲛⲏⲧⲏⲣⲟⲩ ⲉⲧϯ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲛⲉⲙ ⲛⲏⲉⲧϣⲱⲡ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲉⲣⲫⲉⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲓ⳿ⲧⲣⲁⲡⲉⲍⲁ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓⲕⲟⲗⲩⲃⲓⲥⲧⲏⲥ ⲛⲉⲙ ⲛⲓⲕⲁⲑⲉⲇⲣ⳿ⲁ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲏⲉⲧϯ ϭⲣⲟⲙⲡⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲁϥⲥⲟⲥⲟⲩ.
16 Kò sì gba ẹnikẹ́ni láààyè láti gbé ẹrù ọjà títà gba inú tẹmpili wọlé.
ⲓ̅ⲋ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁϥⲭⲱ ⳿ⲛ⳿ϩⲗⲓ ⲁⲛ ⲡⲉ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉϥ⳿ⲉⲛ ⲟⲩ⳿ⲥⲕⲉⲩⲟⲥ ⳿ⲉⲃⲟⲗϩⲓⲧⲉⲛ ⲡⲓⲉⲣⲫⲉⲓ.
17 Gẹ́gẹ́ bí ó ti kọ́ wọn, ó wí pé, “Ṣé a kò ti kọ ọ́ pé: ‘Ilé àdúrà ni a o máa pe ilé mi, ní gbogbo orílẹ̀-èdè?’ Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti sọ ọ́ di ibùgbé àwọn ọlọ́ṣà.”
ⲓ̅ⲍ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁϥϯ⳿ⲥⲃⲱ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁϥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ⳿ⲥ⳿ⲥϧⲏⲟⲩⲧ ϫⲉ ⲡⲁⲏⲓ ⲉⲉⲩ⳿ⲉⲙⲟⲩϯ ⳿ⲉⲣⲟϥ ϫⲉ ⲟⲩⲏⲓ ⳿ⲙ⳿ⲡⲣⲟⲥⲉⲩⲭⲏ ⳿ⲛⲛⲓⲉⲑⲛⲟⲥ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ⲇⲉ ⳿ⲁⲣⲉⲧⲉⲛⲁⲓϥ ⳿ⲙⲃⲏⲃ ⳿ⲛⲥⲟⲛⲓ.
18 Nígbà tí àwọn olórí àlùfáà àti àwọn olùkọ́ òfin gbọ́ ohun tí ó ti ṣe, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí ń gbà èrò bí wọn yóò ti ṣe pa á. Wọ́n bẹ̀rù rògbòdìyàn tí yóò bẹ́ sílẹ̀, nítorí tí àwọn ènìyàn ní ìgbóná ọkàn sí ẹ̀kọ́ rẹ̀.
ⲓ̅ⲏ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁⲩⲥⲱⲧⲉⲙ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲓⲁⲣⲭⲏ⳿ⲉⲣⲉⲩⲥ ⲛⲉⲙ ⲛⲓⲥⲁϧ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁⲩⲕⲱϯ ϫⲉ ⲁⲩⲛⲁⲧⲁⲕⲟϥ ⳿ⲛⲁϣ ⳿ⲛⲣⲏϯ ⲛⲁⲩⲉⲣϩⲟϯ ⲅⲁⲣ ϧⲁⲧⲉϥϩⲏⲡⲓⲙⲏϣ ⲅⲁⲣ ⲧⲏⲣϥ ⲛⲁⲩⲉⲣ⳿ϣⲫⲏⲣⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲧⲉϥ⳿ⲥⲃⲱ.
19 Ní ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ náà, bí ìṣe wọn, Jesu àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ jáde kúrò ní ìlú Jerusalẹmu.
ⲓ̅ⲑ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉϣⲱⲡ ⳿ⲛⲧⲉ ⲣⲟⲩϩⲓ ϣⲱⲡⲓ ⲛⲁϥϩⲏⲗ ⲥⲁⲃⲟⲗ ⳿ⲛϯⲃⲁⲕⲓ.
20 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, bí wọ́n ti ń kọjá lọ, wọ́n rí igi ọ̀pọ̀tọ́ tí Jesu fi bú. Wọ́n rí i pé ó ti gbẹ tigbòǹgbò tigbòǹgbò.
ⲕ̅ⲟⲩⲟϩ ⲉⲩⲥⲓⲛⲓⲱⲟⲩ ⳿ⲛϩⲁⲛ⳿ⲁⲧⲟⲟⲩ⳿ⲓ ⲁⲩⲛⲁⲩ ⳿ⲉϯⲃⲱ ⳿ⲛⲕⲉⲛⲧⲉ ⲁⲥϣⲱⲟⲩ⳿ⲓ ϩⲓ ⲧⲉⲥⲛⲟⲩⲛⲓ.
21 Peteru rántí pé Jesu ti bá igi náà wí. Nígbà náà ni ó sọ fún Jesu pé, “Rabbi, wò ó! Igi ọ̀pọ̀tọ́ tí ìwọ fi bú ti gbẹ!”
ⲕ̅ⲁ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁϥⲉⲣ⳿ⲫⲙⲉⲩⲓ ⳿ⲛϫⲉ Ⲡⲉⲧⲣⲟⲥ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲁϥ ϫⲉ ⲣⲁⲃⲃⲓ ⲓⲥ ϯⲃⲱ ⳿ⲛⲕⲉⲛⲧⲉ ⳿ⲉⲧⲁⲕⲥⲁϩⲟⲩ⳿ⲓ ⳿ⲉⲣⲟⲥ ⲁⲥϣⲱⲟⲩ⳿Ⲓ.
22 Jesu sì dáhùn pé, “Ẹ ní ìgbàgbọ́ nínú Ọlọ́run.
ⲕ̅ⲃ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁϥ⳿ⲉⲣⲟⲩ⳿ⲱ ⳿ⲛϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ⲭⲁ ⲟⲩⲛⲁϩϯ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲫϯ ⳿ⲛⲧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ.
23 Lóòótọ́ ni mò wí fún un yín, bí ẹnikẹ́ni bá wí fún òkè ‘Ṣídìí, gbé ara rẹ sọ sínú Òkun,’ ti kò sì ṣe iyèméjì nínú ọkàn rẹ̀ ṣùgbọ́n tí ó gbàgbọ́ pé ohun tí òun wí yóò ṣẹ, yóò rí bẹ́ẹ̀ fún un.
ⲕ̅ⲅ̅⳿ⲁⲙⲏⲛ ⲅⲁⲣ ϯϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϫⲉ ⲫⲏⲉⲑⲛⲁϫⲟⲥ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲧⲱⲟⲩ ϫⲉ ϥⲓⲧⲕ ⲟⲩⲟϩ ϩⲓⲧⲕ ⳿ⲉ⳿ⲫⲓⲟⲙ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲉϥ⳿ϣⲧⲉⲙϭⲓⲥⲁⲛⲓⲥ ϧⲉⲛⲡⲉϥϩⲏⲧ ⲁⲗⲗⲁ ⳿ⲛⲧⲉϥⲛⲁϩϯ ϫⲉ ⲫⲏ⳿ⲉⲧⲉϥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ϥⲛⲁϣⲱⲡⲓ ⲉϥ⳿ⲉϣⲱⲡⲓ ⲛⲁϥ.
24 Torí náà, mo wí fún yín ohunkóhun tí ẹ bá béèrè fún nínú àdúrà, ẹ ní ìgbàgbọ́ pé, ó tí tẹ̀ yín lọ́wọ́, yóò sì jẹ́ tiyín.
ⲕ̅ⲇ̅ⲉⲑⲃⲉ ⲫⲁⲓ ϯϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϫⲉ ϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⳿ⲉⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁⲉⲣ⳿ⲉⲧⲓⲛ ⳿ⲙⲙⲟϥ ϧⲉⲛ ⲟⲩ⳿ⲡⲣⲟⲥⲉⲩⲭⲏ ⲛⲁϩϯ ϫⲉ ⳿ⲁⲣⲉⲧⲉⲛϭⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲥ⳿ⲉϣⲱⲡⲓ ⲛⲱⲧⲉⲛ.
25 Nígbà tí ẹ bá ń gbàdúrà, ẹ kọ́kọ́ dáríjì, bí ẹ̀yin bá ní ohunkóhun sí ẹnikẹ́ni, kí baba yín tí ń bẹ ní ọ̀run bá à le dárí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ tiyín náà jì yín.”
ⲕ̅ⲉ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉϣⲱⲡ ⳿ⲁⲣⲉⲧⲉⲛϣⲁⲛ⳿ⲟϩⲓ ⳿ⲉⲣⲁⲧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⳿ⲉⲉⲣ⳿ⲡⲣⲟⲥⲉⲩⲭⲉⲥⲑⲉ ⲭⲱ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲙⲡ⳿ⲉⲧⲉ ⲟⲩⲟⲛ ⳿ⲛⲧⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲉⲣⲟϥ ϩⲓⲛⲁ ϩⲱϥ ⲡⲉⲧⲉⲛⲓⲱⲧ ⲉⲧϧⲉⲛ ⲛⲓⲫⲏⲟⲩ⳿ⲓ ⳿ⲛⲧⲉϥⲭⲱ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛⲛⲉⲧⲉⲛⲡⲁⲣⲁ⳿ⲡⲧⲱⲙⲁ.
ⲕ̅ⲋ̅ⲟⲩⲟϩ ϩⲟⲧⲁⲛ ⲛⲧⲉⲧⲉⲛϭⲧⲉⲙⲭⲱ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲟⲩⲇⲉ ⲡⲉⲧⲉⲛⲓⲱⲧ ⲉⲧϧⲉⲛ ⲛⲓⲫⲏⲟⲩ⳿ⲓ ⲛⲛⲉϥⲭⲱ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲁⲛ ⲙⲡⲉⲧⲉⲛⲡⲁⲣⲁⲡⲧⲱⲙⲁ.
27 Lẹ́yìn èyí, wọ́n tún padà sí Jerusalẹmu. Bí Jesu ti ń rìn kiri ni tẹmpili, àwọn olórí àlùfáà àti àwọn olùkọ́ òfin pẹ̀lú àwọn àgbàgbà Júù wá sọ́dọ̀ rẹ̀.
ⲕ̅ⲍ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩ⳿ⲓ ⲟⲛ ⳿ⲉⲒⲗ̅ⲏ̅ⲙ̅ ⲟⲩⲟϩ ⲉϥⲙⲟϣⲓ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲉⲣⲫⲉⲓ ⲁⲩ⳿ⲓ ϩⲁⲣⲟϥ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲓⲁⲣⲭⲏ⳿ⲉⲣⲉⲩⲥ ⲛⲉⲙ ⲛⲓⲥⲁϧ ⲛⲉⲙ ⲛⲓ⳿ⲡⲣⲉⲥⲃⲩⲧⲉⲣⲟⲥ.
28 Wọ́n béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Àṣẹ wo ni ó fi ń ṣe nǹkan yìí? Ta ni ó sì fún ọ ni àṣẹ yìí láti máa ṣe nǹkan wọ̀nyí?”
ⲕ̅ⲏ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁⲩϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲛⲁϥ ϫⲉ ⲁⲕ⳿⳿ⲓⲣⲓ ⳿ⲛⲛⲁⲓ ϧⲉⲛ ⲁϣ ⳿ⲛⲉⲣϣⲓϣⲓ ⲓⲉ ⲛⲓⲙ ⲡⲉⲧⲁϥϯ ⲛⲁⲕ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲉⲣϣⲓϣⲓ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉⲕ⳿⳿ⲓⲣⲓ ⳿ⲛⲛⲁⲓ.
29 Jesu dá wọn lóhùn pé, “Èmi yóò bi yín léèrè ọ̀rọ̀ kan, kí ẹ sì dá mi lóhùn, èmi yóò sọ fún yín àṣẹ tí èmi fi ń ṣe nǹkan wọ̀nyí.”
ⲕ̅ⲑ̅Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲇⲉ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ϯⲛⲁϣⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⳿ⲉⲟⲩⲥⲁϫⲓ ⳿ⲛⲟⲩⲱⲧ ⳿ⲁⲣⲓⲟⲩⲱ ⲛⲏⲓ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ϩⲱ ϯⲛⲁϫⲟⲥ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϫⲉ ⲁⲓ⳿⳿ⲓⲣⲓ ⳿ⲛⲛⲁⲓϧⲉⲛ ⲁϣ ⳿ⲛⲉⲣϣⲓϣⲓ.
30 Ìtẹ̀bọmi Johanu láti ọ̀run wa ni, tàbí láti ọ̀dọ̀ ènìyàn? “Ẹ dá mi lóhùn!”
ⲗ̅ⲡⲓⲱⲙⲥ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲓⲱⲁⲛⲛⲏⲥ ⲛⲉ ⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⳿ⲧⲫⲉ ⲡⲉ ϣⲁⲛ ⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⲛⲓⲣⲱⲙⲓ ⳿ⲁⲣⲓⲟⲩⲱ ⲛⲏⲓ.
31 Wọ́n bá ara wọn jíròrò pé, “Bí a bá wí pé, ‘Láti ọ̀run wá ni,’ òun ó wí pé, ‘Nígbà tí ẹ mọ̀ bẹ́ẹ̀, èéṣe tí ẹ kò fi gbà à gbọ́?’
ⲗ̅ⲁ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁⲩⲙⲟⲕⲙⲉⲕ ⲛⲉⲙ ⳿ⲛⲛⲟⲩ⳿ⲉⲣⲏⲟⲩ ⲉⲩϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲁⲛϣⲁⲛϫⲟⲥ ϫⲉ ⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⳿ⲧⲫⲉ ⲡⲉ ⳿ϥⲛⲁϫⲟⲥ ϫⲉ ⲉⲑⲃⲉ ⲟⲩ ⳿ⲙⲡⲉⲧⲉⲛⲛⲁϩϯ ⳿ⲉⲣⲟϥ.
32 Ṣùgbọ́n bí a bá wí pé, àti ọ̀dọ̀ ènìyàn, wọ́n bẹ̀rù àwọn ènìyàn, nítorí pé gbogbo ènìyàn ló gbàgbọ́ pé wòlíì gidi ni Johanu.”
ⲗ̅ⲃ̅ⲁⲗⲗⲁ ⳿ⲛⲧⲉⲛϫⲟⲥ ϫⲉ ⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⲛⲓⲣⲱⲙⲓ ⲧ⳿ⲉⲛⲉⲣϩⲟϯ ϧⲁ⳿ⲧϩⲏ ⳿ⲙⲡⲓⲙⲏϣ ⲛⲁⲣⲉ Ⲓⲱⲁⲛⲛⲏⲥ ⲅⲁⲣ ⳿ⲛⲧⲟⲧⲟⲩ ⲧⲏⲣⲟⲩ ϫⲉ ⲟⲛⲧⲱⲥ ⲛⲉ ⲟⲩ⳿ⲡⲣⲟⲫⲏⲧⲏⲥ ⲡⲉ.
33 Nítorí náà, wọ́n kọjú sí Jesu wọn sì dáhùn pé, “Àwa kò mọ̀.” Nígbà náà ni Jesu wí pé, “Níwọ́n ìgbà tí ẹ kò lè dáhùn ìbéèrè mi, Èmi náà kì yóò sọ fún yín àṣẹ tí mo fi ń ṣe nǹkan wọ̀nyí.”
ⲗ̅ⲅ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁⲩ⳿ⲉⲣⲟⲩ⳿ⲱ ⳿ⲛⲒⲏ̅ⲥ̅ ⲡⲉϫⲱⲟⲩ ϫⲉ ⲧⲉⲛ⳿ⲉⲙⲓ ⲁⲛ ⲟⲩⲟϩ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ϩⲱϥ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ⲟⲩⲇⲉ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ϩⲱ ϯⲛⲁϫⲟⲥ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⲁⲛ ϫⲉ ⲁⲓ⳿⳿ⲓⲣⲓ ϧⲉⲛ ⲁϣ ⳿ⲛⲉⲣϣⲓϣⲓ.