< Mark 10 >

1 Nígbà náà, Jesu kúrò níbẹ̀, ó sì wá sí ẹkùn Judea níhà òkè odò Jordani. Àwọn ènìyàn sì tún tọ̀ ọ́ wá, bí i ìṣe rẹ̀, ó sì kọ́ wọn.
Wychodząc z Kafarnaum Jezus skierował się na południe, do Judei i w okolice leżące po drugiej stronie Jordanu. A gdy nauczał, jak zwykle otoczony przez tłumy,
2 Àwọn Farisi kan tọ̀ ọ́ wá, láti dán an wò. Wọ́n béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Ǹjẹ́ ó ha tọ̀nà fún ènìyàn láti kọ ìyàwó rẹ̀ sílẹ̀?”
podeszli faryzeusze i—chcąc Go sprowokować do jakiejś niefortunnej wypowiedzi—zapytali Go: —Czy zezwalasz na rozwody?
3 Jesu béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Kí ni Mose pàṣẹ fún un yín?”
—A co na ten temat powiedział Mojżesz?—spytał ich Jezus.
4 Wọ́n dáhùn pé, “Mose yọ̀ǹda fún wa láti kọ ìwé ìkọ̀sílẹ̀ fún un, kí a sì fi sílẹ̀.”
—Pozwolił wręczyć żonie dokument rozwodowy i odprawić ją—odrzekli.
5 Ṣùgbọ́n Jesu dá wọn lóhùn, ó sì wí pé, “Nítorí líle àyà yín ni Mose fi kọ òfin yìí fun un yín.
—Mojżesz zezwolił na to tylko z powodu waszych zatwardziałych serc—odparł Jezus.
6 Ṣùgbọ́n láti ìgbà tí ayé ti ṣẹ̀, Ọlọ́run dá wọn ní akọ àti abo.
—Ale nie taki był Boży zamiar. Już na samym początku Bóg stworzył bowiem mężczyznę i kobietę.
7 Nítorí ìdí èyí, ọkùnrin yóò fi baba àti ìyá rẹ̀ sílẹ̀ yóò sì fi ara mọ́ aya rẹ̀.
Dlatego właśnie mężczyzna powinien opuścić rodziców
8 Òun àti ìyàwó rẹ̀ yóò di ara kan náà. Nítorí náà, wọn kì í túnṣe méjì mọ́ bí kò ṣe ẹyọ ọ̀kan ṣoṣo.
i złączyć się z żoną, aby ci dwoje stali się jednym ciałem.
9 Nítorí náà ohun ti Ọlọ́run bá sọ dọ̀kan, ki ẹnikẹ́ni máa ṣe yà wọ́n.”
Żaden człowiek nie ma prawa rozdzielać tego, co połączył Bóg.
10 Lẹ́yìn náà, nígbà tí Jesu nìkan wà nínú ilé pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, wọ́n tún béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ nípa ohun kan náà.
Gdy później znalazł się z uczniami w domu, ci powrócili do tego tematu.
11 Jesu túbọ̀ ṣe àlàyé fún wọn pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ aya rẹ̀ sílẹ̀ tí ó bá sì fẹ́ ẹlòmíràn, irú ọkùnrin bẹ́ẹ̀ ṣe panṣágà sí obìnrin tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ gbé níyàwó.
Wtedy im powiedział: —Jeśli mężczyzna rozwodzi się z żoną i poślubia inną kobietę, dopuszcza się grzechu niewierności małżeńskiej.
12 Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́, bí obìnrin kan bá kọ ọkọ rẹ̀ sílẹ̀ tí ó sì fẹ́ ọkùnrin mìíràn, irú obìnrin bẹ́ẹ̀ ṣe panṣágà.”
Podobnie żona, jeśli porzuca męża, aby powtórnie wyjść za mąż, dopuszcza się grzechu niewierności.
13 Lẹ́yìn èyí, àwọn ènìyàn bẹ̀rẹ̀ sí í gbé àwọn ọmọ wẹ́wẹ́ tọ Jesu wá kí ó lè súre fún wọn. Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ kígbe mọ́ àwọn tí ń gbé àwọn ọmọdé wọ̀nyí bọ̀ pé wọn kò gbọdọ̀ yọ Jesu lẹ́nu rárá.
Zdarzyło się też, że przyprowadzono do Jezusa dzieci, prosząc, aby je pobłogosławił. Uczniowie jednak odsuwali je, nie chcąc, aby Mu przeszkadzały.
14 Ṣùgbọ́n nígbà tí Jesu rí ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀, inú rẹ̀ kò dùn sí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀. Nítorí náà, ó sọ fún wọn pé, “Ẹ jẹ́ kí àwọn ọmọdé kékeré wá sọ́dọ̀ mi. Ẹ má ṣe dá wọn lẹ́kun nítorí pé irú wọn ni ìjọba Ọlọ́run.
Widząc to, Jezus oburzył się na nich i rzekł: —Nie zabraniajcie dzieciom przychodzić do Mnie, gdyż do takich jak one należy królestwo Boże.
15 Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ẹnikẹ́ni tí kò bá gba ìjọba Ọlọ́run bí ọmọ kékeré, kì yóò le è wọ inú rẹ̀.”
Zapewniam was: Jeśli ktoś nie przyjdzie do Boga tak, jak dziecko przychodzi do ojca, nie będzie miał wstępu do Jego królestwa.
16 Nígbà náà, Jesu gbé àwọn ọmọ náà lé ọwọ́ rẹ̀, ó gbé ọwọ́ lé orí wọn. Ó sì súre fún wọn.
I przytulał dzieci, i kładł na nie ręce, błogosławiąc je.
17 Bí Jesu ti bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò rẹ, ọkùnrin kan sáré wá sọ́dọ̀ rẹ̀. Ó sì kúnlẹ̀, ó béèrè pé, “Olùkọ́ rere, kí ni èmi yóò ṣe láti jogún ìyè àìnípẹ̀kun?” (aiōnios g166)
W trakcie przygotowań do dalszej drogi przybiegł do Jezusa jakiś młody człowiek. Ukląkł przed Nim i zapytał: —Dobry nauczycielu, co mam czynić, aby osiągnąć życie wieczne? (aiōnios g166)
18 Jesu béèrè pé, arákùnrin, “Èéṣe tí o fi ń pè mí ní ẹni rere? Ẹni rere kan kò sí Ọlọ́run nìkan ni ẹni rere.
—Dlaczego nazywasz Mnie „dobrym”?—zapytał Jezus. —Naprawdę dobry jest tylko Bóg.
19 Ìwọ mọ àwọn òfin bí: ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ pànìyàn, ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe panṣágà, ìwọ kò gbọdọ̀ jalè, ìwọ kò gbọdọ̀ purọ́, ìwọ kò gbọdọ̀ rẹ́ ọmọnìkejì jẹ, bọ̀wọ̀ fún baba àti ìyá rẹ.’”
Jeśli zaś chodzi o twoje pytanie, to znasz chyba przykazania: „Nie zabijaj, bądź wierny w małżeństwie, nie kradnij, nie składaj fałszywych zeznań, szanuj rodziców!”?
20 Ọkùnrin náà dáhùn pé, “Olùkọ́, gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni èmi ń ṣe láti ìgbà èwe mi wá.”
—Nauczycielu! Nigdy nie przekroczyłem żadnego z nich—odpowiedział.
21 Jesu wò ó tìfẹ́tìfẹ́. Ó wí fún un pé, “Bí ó bá rí bẹ́ẹ̀, ohun kan ló kù fún ọ láti ṣe, lọ nísinsin yìí, ta gbogbo nǹkan tí o ní, kí o sì pín owó náà fún àwọn aláìní ìwọ yóò sì ní ìṣúra ní ọ̀run, sì wá, kí ó sì máa tọ̀ mí lẹ́yìn.”
Jezus spojrzał na niego z głęboką miłością i rzekł: —Zatem jedno pozostało ci do zrobienia: Idź i sprzedaj swój majątek, a pieniądze rozdaj biednym. To zapewni ci skarb w niebie. Potem wróć i chodź ze Mną.
22 Nígbà tí ọkùnrin yìí gbọ́ èyí, ojú rẹ̀ korò, ó sì lọ pẹ̀lú ìbànújẹ́, nítorí pé ó ní ọrọ̀ púpọ̀.
Na te słowa młody człowiek spochmurniał i odszedł zasmucony; był bowiem bardzo bogaty.
23 Jesu wò ó bí ọkùnrin náà ti ń lọ. Ó yípadà, ó sì sọ fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Àní, ohun ìṣòro ni fún ọlọ́rọ̀ láti wọ ìjọba Ọlọ́run!”
Jezus odprowadził go wzrokiem i powiedział do uczniów: —Oto jak trudno jest bogatym wejść do królestwa Bożego.
24 Ọ̀rọ̀ yìí ya àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ lẹ́nu. Jesu tún sọ fún wọn pé, “Ẹyin ọmọ yóò tí ṣòro tó fún àwọn tí ó ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú ọrọ̀ láti wọ ìjọba Ọlọ́run.
A ponieważ zdumiało to uczniów, dodał: —Nie sposób wejść do Bożego królestwa, jeśli pokłada się nadzieję w bogactwie.
25 Ó rọrùn fún ìbákasẹ láti gba ojú abẹ́rẹ́ wọlé jù fún ọlọ́rọ̀ kan láti wọ ìjọba ọ̀run.”
Łatwiej wielbłądowi przejść przez ucho od igły, niż bogatemu człowiekowi wejść do królestwa Bożego.
26 Ẹnu túbọ̀ ya àwọn ọmọ-ẹ̀yìn sí i. Wọ́n béèrè wí pé, “Tí ó bá rí bẹ́ẹ̀, ta ni nínú ayé ni ó lè ní ìgbàlà?”
Słowa te poważnie zastanowiły uczniów: —Kto więc może być zbawiony?—pytali.
27 Jesu wò wọ́n, ó sì wí fún wọn pé, “Ènìyàn ní èyí kò ṣe é ṣe fún ṣùgbọ́n kì í ṣe fún Ọlọ́run, nítorí ohun gbogbo ni ṣíṣe fún Ọlọ́run.”
Jezus spojrzał na nich i rzekł: —To przekracza ludzkie możliwości, ale dla Boga wszystko jest możliwe.
28 Nígbà náà ni Peteru kọjú sí Jesu, ó wí pé, “Àwa ti fi ohun gbogbo sílẹ̀, a sì ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.”
—My zostawiliśmy wszystko i poszliśmy za Tobą—odezwał się Piotr.
29 Jesu dáhùn pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún un yín pé, kò sí ẹnikẹ́ni tí ó fi ohunkóhun sílẹ̀ bí: ilé, tàbí àwọn arákùnrin, tàbí àwọn arábìnrin, tàbí ìyá, tàbí baba, tàbí àwọn ọmọ tàbí ohun ìní nítorí mi àti nítorí ìyìnrere,
—Zapewniam was—odpowiedział Jezus—że każdy, kto z miłości do Mnie i w celu głoszenia dobrej nowiny opuścił dom, braci, siostry, matkę, ojca, dzieci albo posiadłości,
30 tí a kì yóò fún padà ní ọgọọgọ́rùn-ún àwọn ilé, tàbí arákùnrin, tàbí arábìnrin, tàbí ìyá, tàbí ọmọ, tàbí ilẹ̀, àti inúnibíni pẹ̀lú. Gbogbo nǹkan wọ̀nyí yóò jẹ́ tirẹ̀ ní ayé yìí àti pé ní ayé tó ń bọ̀ yóò ní ìyè àìnípẹ̀kun. (aiōn g165, aiōnios g166)
otrzyma w zamian sto razy więcej domów, braci, sióstr, matek, dzieci oraz posiadłości, ale spotkają go też prześladowania! Oprócz tego, co otrzyma tu, na ziemi, czeka go życie wieczne w przyszłym świecie. (aiōn g165, aiōnios g166)
31 Ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀ àwọn tí ó síwájú ni yóò di ẹni ìkẹyìn, àwọn tí ó sì kẹ́yìn yóò síwájú.”
Wtedy wielu ludzi, obecnie uznawanych za wielkich, przestanie się liczyć, a inni, teraz uznawani za najmniejszych, będą wielkimi.
32 Nísinsin yìí, wọ́n wà lójú ọ̀nà sí Jerusalẹmu. Jesu sì ń lọ níwájú wọn, bí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn ti ń tẹ̀lé e, ìbẹ̀rù kún ọkàn wọn. Ó sì tún mú àwọn méjìlá sí apá kan, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ṣàlàyé ohun gbogbo tí a ó ṣe sí i fún wọn.
Podążali teraz w kierunku Jerozolimy. Jezus szedł przodem, a za Nim uczniowie, pełni lęku i trwogi. Wtedy wziął Dwunastu na bok i jeszcze raz powiedział im o wszystkim, co Go czeka:
33 Ó sọ fún wọn pé, “Àwa ń gòkè lọ Jerusalẹmu, a ó sì fi Ọmọ Ènìyàn lé àwọn olórí àlùfáà àti àwọn olùkọ́ òfin lọ́wọ́. Wọn ni yóò dá lẹ́bi ikú. Wọn yóò sì fà á lé ọwọ́ àwọn aláìkọlà.
—Gdy znajdziemy się w Jerozolimie—mówił—Ja, Syn Człowieczy, zostanę schwytany i postawiony przed najwyższymi kapłanami i przywódcami religijnymi, którzy skażą Mnie na śmierć i wydadzą w ręce Rzymian, aby Mnie zabili.
34 Wọn yóò fi ṣe ẹlẹ́yà, wọn yóò tutọ́ sí ní ara, wọn yóò nà pẹ̀lú pàṣán wọn. Wọn yóò sì pa, ṣùgbọ́n lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́ta yóò tún jíǹde.”
Będą śmiać się ze Mnie i pluć na Mnie; ubiczują Mnie i w końcu zabiją. Lecz po trzech dniach powrócę do życia.
35 Lẹ́yìn èyí, Jakọbu àti Johanu, àwọn ọmọ Sebede wá sọ́dọ̀ Jesu. Wọ́n sì bá a sọ̀rọ̀ kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́, wọ́n wí pé, “Olùkọ́, inú wa yóò dùn bí ìwọ bá lè ṣe ohunkóhun tí a bá béèrè fún wa.”
Potem podeszli do Niego Jakub i Jan, synowie Zebedeusza, i rzekli: —Nauczycielu! Mamy do Ciebie prośbę.
36 Jesu béèrè pé, “Kí ni Ẹ̀yin ń fẹ́ kí èmi ó ṣe fún un yín?”
—Jaką?—zapytał.
37 Wọ́n bẹ̀bẹ̀ pé, “Jẹ́ kí ọ̀kan nínú wa jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ àti ẹnìkejì ní ọwọ́ òsì nínú ògo rẹ!”
—Chcielibyśmy zasiadać w Twoim królestwie tuż obok Ciebie—po prawej i lewej stronie.
38 Ṣùgbọ́n Jesu dá wọn lóhùn pé, “Ẹ kò mọ ohun tí ẹ̀ ń béèrè! Ṣe ẹ lè mu nínú ago kíkorò tí èmi ó mú tàbí a lè bamitiisi yín pẹ̀lú irú ì bamitiisi ìjìyà tí a ó fi bamitiisi mi?”
—Nie wiecie, o co prosicie!—odrzekł im Jezus. —Czy jesteście gotowi wypić mój „kielich cierpienia”? Albo przejść chrzest, jaki jest dla Mnie przeznaczony?
39 Àwọn méjèèjì dáhùn pé, “Àwa pẹ̀lú lè ṣe bẹ́ẹ̀.” Jesu wí fún wọn pé, “Lóòótọ́ ni ẹ̀yin ó mu ago ti èmi yóò mu, àti bamitiisi tí a sí bamitiisi mi ni a ó fi bamitiisi yín,
—Tak—opowiedzieli bracia. —Rzeczywiście, wypijecie ten „kielich” i przejdziecie ten chrzest—kontynuował Jezus—
40 ṣùgbọ́n láti jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún mi àti ní ọwọ́ òsì mi kì ì ṣe ti èmi láti fi fún ni: bí kò ṣe fún àwọn ẹni tí a ti pèsè rẹ̀ sílẹ̀ fún.”
ale nie mam prawa posadzić was na tronie obok siebie. Te miejsca są już rozdzielone.
41 Nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn mẹ́wàá ìyókù gbọ́ ohun tí Jakọbu àti Johanu béèrè, wọ́n bínú.
Gdy pozostałych dziesięciu uczniów dowiedziało się o tej prośbie, oburzyli się na Jakuba i Jana.
42 Nítorí ìdí èyí, Jesu pè wọ́n sọ́dọ̀, ó sì wí fún wọn pé, “Gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti mọ̀ pé, àwọn ọba àti àwọn kèfèrí ń lo agbára lórí àwọn ènìyàn.
Wtedy Jezus zawołał wszystkich do siebie i powiedział: —Jak wiecie, wielcy tego świata nadużywają swojej władzy nad ludźmi.
43 Ṣùgbọ́n láàrín yín ko gbọdọ̀ ri bẹ. Ẹnikẹ́ni tí ó bá fẹ́ di olórí nínú yín gbọdọ̀ ṣe ìránṣẹ́.
Lecz wśród was powinno być inaczej. Jeśli ktoś z was chce być wielki, powinien stać się sługą.
44 Ẹnikẹ́ni tí ó fẹ́ di aṣáájú nínú yín gbọdọ̀ ṣe ìránṣẹ́ gbogbo yín.
A kto chce być największy ze wszystkich, musi stać się niewolnikiem wszystkich.
45 Nítorí, Èmi, Ọmọ Ènìyàn kò wá sí ayé kí ẹ lè ṣe ìránṣẹ́ fún mi, ṣùgbọ́n láti lè ṣe ìránṣẹ́ fun àwọn ẹlòmíràn, àti láti fi ẹ̀mí rẹ̀ ṣe ìràpadà ọ̀pọ̀ ènìyàn.”
Przecież nawet Ja, Syn Człowieczy, nie przyszedłem po to, żeby Mi służono, lecz aby służyć innym i złożyć własne życie jako okup za wielu ludzi.
46 Wọ́n dé Jeriko, bí Jesu àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ àti ọ̀pọ̀ ènìyàn ti fẹ́ kúrò ní ìlú Jeriko, ọkùnrin afọ́jú kan, Bartimeu, ọmọ Timeu jókòó lẹ́gbẹ̀ẹ́ ọ̀nà ó ń ṣagbe.
Rozmawiając, dotarli do Jerycha. Gdy wychodzili z miasta, ciągnął już za nimi wielki tłum. A pewien niewidomy żebrak, Bartymeusz (to znaczy: syn Tymeusza) siedział tam przy drodze.
47 Nígbà tí Bartimeu gbọ́ pé Jesu ti Nasareti wà nítòsí, o bẹ̀rẹ̀ sí kígbe lóhùn rara pé, “Jesu ọmọ Dafidi, ṣàánú fún mi.”
Usłyszał, że Jezus z Nazaretu znajduje się w pobliżu, i zaczął wołać: —Jezusie, potomku króla Dawida, zmiłuj się nade mną!
48 Àwọn tó wà níbẹ̀ kígbe mọ́ ọn pé, “Pa ẹnu rẹ mọ́.” Ṣùgbọ́n dípò kí ó pa ẹnu mọ́, ṣe ló ń kígbe lóhùn rara pé, “Jesu ọmọ Dafidi ṣàánú fún mi.”
—Cicho bądź!—krzyczeli na niego ludzie. On jednak tym głośniej wołał: —Potomku Dawida, zmiłuj się nade mną!
49 Nígbà tí Jesu gbọ́ igbe rẹ̀, ó dẹ́sẹ̀ dúró lójú ọ̀nà, ó sì wí pé, “Ẹ pè é kí ó wá sọ́dọ̀ mi.” Nítorí náà wọ́n pe ọkùnrin afọ́jú náà, wọ́n wí pé, “Tújúká! Dìde lórí ẹsẹ̀ rẹ! Ó ń pè ọ́.”
Jezus zatrzymał się i rzekł: —Zawołajcie go tutaj! Poszli więc po niego i powiedzieli: —Masz szczęście, człowieku! Chodź, On cię woła!
50 Lẹ́sẹ̀kan náà, Bartimeu bọ́ agbádá rẹ̀ sọnù, ó fò sókè, ó sì wá sọ́dọ̀ Jesu.
Bartymeusz zrzucił płaszcz, zerwał się na nogi i ruszył do Jezusa.
51 Jesu béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Kí ni ìwọ fẹ́ kí èmi kí ó ṣe fún ọ?” Afọ́jú náà dáhùn pé, “Rabbi, jẹ́ kí èmi kí ó ríran.”
—Co mogę dla ciebie zrobić?—zapytał Jezus. —Nauczycielu!—prosił niewidomy. —Chciałbym widzieć!
52 Jesu wí fún un pé, “Máa lọ, ìgbàgbọ́ rẹ ti mú ọ láradá.” Lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀, ọkùnrin afọ́jú náà ríran ó sì ń tẹ̀lé Jesu lọ ní ọ̀nà.
—Dobrze, niech się tak stanie!—powiedział Jezus. —Twoja wiara cię uzdrowiła. I natychmiast niewidomy odzyskał wzrok i poszedł z Nim.

< Mark 10 >