< Mark 1 >

1 Ìbẹ̀rẹ̀ ìyìnrere nípa Jesu Kristi, Ọmọ Ọlọ́run.
ཨཱིཤྭརཔུཏྲསྱ ཡཱིཤུཁྲཱིཥྚསྱ སུསཾཝཱདཱརམྦྷཿ།
2 Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ nínú ìwé wòlíì Isaiah pé, “Èmi yóò ran oníṣẹ́ mi síwájú rẹ, Ẹni tí yóò tún ọ̀nà rẹ ṣe.”
བྷཝིཥྱདྭཱདིནཱཾ གྲནྠེཥུ ལིཔིརིཏྠམཱསྟེ, པཤྱ སྭཀཱིཡདཱུཏནྟུ ཏཝཱགྲེ པྲེཥཡཱམྱཧམ྄། གཏྭཱ ཏྭདཱིཡཔནྠཱནཾ ས ཧི པརིཥྐརིཥྱཏི།
3 “Ohùn ẹni tí ń kígbe ní ijù, ‘Ẹ tún ọ̀nà Olúwa ṣe, ẹ ṣe ojú ọ̀nà rẹ̀ kí ó tọ́.’”
"པརམེཤསྱ པནྠཱནཾ པརིཥྐུརུཏ སཪྻྭཏཿ། ཏསྱ རཱཛཔཐཉྩཻཝ སམཱནཾ ཀུརུཏཱདྷུནཱ། " ཨིཏྱེཏཏ྄ པྲཱནྟརེ ཝཱཀྱཾ ཝདཏཿ ཀསྱཙིདྲཝཿ༎
4 Johanu dé, ẹni tí ó ń tẹnibọmi ní aginjù, tí ó sì ń wàásù ìtẹ̀bọmi ìrònúpìwàdà fún ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀.
སཨེཝ ཡོཧན྄ པྲཱནྟརེ མཛྫིཏཝཱན྄ ཏཐཱ པཱཔམཱརྫནནིམིཏྟཾ མནོཝྱཱཝརྟྟཀམཛྫནསྱ ཀཐཱཉྩ པྲཙཱརིཏཝཱན྄།
5 Gbogbo àwọn tí ń gbé ní agbègbè Judea, àti gbogbo ènìyàn Jerusalẹmu jáde tọ̀ ọ́ lọ, a sì ti ọwọ́ rẹ̀ tẹ gbogbo wọn bọ omi ni odò Jordani, wọ́n ń jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
ཏཏོ ཡིཧཱུདཱདེཤཡིརཱུཤཱལམྣགརནིཝཱསིནཿ སཪྻྭེ ལོཀཱ བཧི རྦྷཱུཏྭཱ ཏསྱ སམཱིཔམཱགཏྱ སྭཱནི སྭཱནི པཱཔཱནྱངྒཱིཀྲྀཏྱ ཡརྡྡནནདྱཱཾ ཏེན མཛྫིཏཱ བབྷཱུཝུཿ།
6 Johanu sì wọ aṣọ irun ìbákasẹ. Ó sì di àmùrè awọ mọ́ ẹ̀gbẹ́ rẹ̀. Eṣú àti oyin ìgàn sì ni oúnjẹ rẹ̀.
ཨསྱ ཡོཧནཿ པརིདྷེཡཱནི ཀྲམེལཀལོམཛཱནི, ཏསྱ ཀཊིབནྡྷནཾ ཙརྨྨཛཱཏམ྄, ཏསྱ བྷཀྵྱཱཎི ཙ ཤཱུཀཀཱིཊཱ ཝནྱམདྷཱུནི ཙཱསན྄།
7 Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í wàásù wí pé, “Ẹnìkan tí ó tóbi jù mí lọ ń bọ̀ lẹ́yìn mi, okùn bàtà ẹsẹ̀ ẹni tí èmi kò tó ẹni tí ń tú.
ས པྲཙཱརཡན྄ ཀཐཡཱཉྩཀྲེ, ཨཧཾ ནམྲཱིབྷཱུཡ ཡསྱ པཱདུཀཱབནྡྷནཾ མོཙཡིཏུམཔི ན ཡོགྱོསྨི, ཏཱདྲྀཤོ མཏྟོ གུརུཏར ཨེཀཿ པུརུཥོ མཏྤཤྩཱདཱགཙྪཏི།
8 Èmi ń fi omi ṣe ìtẹ̀bọmi yín, ṣùgbọ́n Òun yóò fi Ẹ̀mí Mímọ́ ṣe ìtẹ̀bọmi yín.”
ཨཧཾ ཡུཥྨཱན྄ ཛལེ མཛྫིཏཝཱན྄ ཀིནྟུ ས པཝིཏྲ ཨཱཏྨཱནི སཾམཛྫཡིཥྱཏི།
9 Ó sì ṣe ní ọjọ́ kan Jesu ti Nasareti ti Galili jáde wá, a sì ti ọwọ́ Johanu ṣe ìtẹ̀bọmi fún ní odò Jordani.
ཨཔརཉྩ ཏསྨིནྣེཝ ཀཱལེ གཱལཱིལྤྲདེཤསྱ ནཱསརདྒྲཱམཱད྄ ཡཱིཤུརཱགཏྱ ཡོཧནཱ ཡརྡྡནནདྱཱཾ མཛྫིཏོ྅བྷཱུཏ྄།
10 Lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ tí Jesu ń ti inú omi jáde wá, ó rí ọ̀run tí ó ṣí sílẹ̀, Ẹ̀mí Mímọ́ bí àdàbà sọ̀kalẹ̀ lé e lórí.
ས ཛལཱདུཏྠིཏམཱཏྲོ མེགྷདྭཱརཾ མུཀྟཾ ཀཔོཏཝཏ྄ སྭསྱོཔརི ཨཝརོཧནྟམཱཏྨཱནཉྩ དྲྀཥྚཝཱན྄།
11 Ohùn kan sì ti ọ̀run wá wí pé, “Ìwọ ni àyànfẹ́ Ọmọ mi, ẹni tí inú mi dùn sí gidigidi.”
ཏྭཾ མམ པྲིཡཿ པུཏྲསྟྭཡྻེཝ མམམཧཱསནྟོཥ ཨིཡམཱཀཱཤཱིཡཱ ཝཱཎཱི བབྷཱུཝ།
12 Lẹ́sẹ̀kan náà, Ẹ̀mí Mímọ́ sì darí Jesu sí ijù,
ཏསྨིན྄ ཀཱལེ ཨཱཏྨཱ ཏཾ པྲཱནྟརམདྷྱཾ ནིནཱཡ།
13 Ó sì wà ní ogójì ọjọ́ ní aginjù. A sì ti ọwọ́ Satani dán an wò, ó sì wà pẹ̀lú àwọn ẹranko ìgbẹ́. Àwọn angẹli sì ń ṣe ìránṣẹ́ fún un.
ཨཐ ས ཙཏྭཱརིཾཤདྡིནཱནི ཏསྨིན྄ སྠཱནེ ཝནྱཔཤུབྷིཿ སཧ ཏིཥྛན྄ ཤཻཏཱནཱ པརཱིཀྵིཏཿ; པཤྩཱཏ྄ སྭརྒཱིཡདཱུཏཱསྟཾ སིཥེཝིརེ།
14 Lẹ́yìn ìgbà tí ọba Herodu ti fi Johanu sínú ẹ̀wọ̀n tan, Jesu lọ sí Galili, ó ń wàásù ìyìnrere ti ìjọba Ọlọ́run.
ཨནནྟརཾ ཡོཧནི བནྡྷནཱལཡེ བདྡྷེ སཏི ཡཱིཤུ རྒཱལཱིལྤྲདེཤམཱགཏྱ ཨཱིཤྭརརཱཛྱསྱ སུསཾཝཱདཾ པྲཙཱརཡན྄ ཀཐཡཱམཱས,
15 Ó sì kéde wí pé, “Àkókò náà dé wàyí, ìjọba Ọlọ́run kù sí dẹ̀dẹ̀. Ẹ yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ yín, kí ẹ sì gba ìyìnrere yìí gbọ́.”
ཀཱལཿ སམྤཱུརྞ ཨཱིཤྭརརཱཛྱཉྩ སམཱིཔམཱགཏཾ; ཨཏོཧེཏོ ཪྻཱུཡཾ མནཱཾསི ཝྱཱཝརྟྟཡདྷྭཾ སུསཾཝཱདེ ཙ ཝིཤྭཱསིཏ།
16 Ní ọjọ́ kan, bí Jesu ti ń rìn létí Òkun Galili, Ó rí Simoni àti Anderu arákùnrin rẹ̀, wọ́n ń fi àwọ̀n wọn pẹja torí pé apẹja ni wọ́n.
ཏདནནྟརཾ ས གཱལཱིལཱིཡསམུདྲསྱ ཏཱིརེ གཙྪན྄ ཤིམོན྄ ཏསྱ བྷྲཱཏཱ ཨནྡྲིཡནཱམཱ ཙ ཨིམཽ དྭཽ ཛནཽ མཏྶྱདྷཱརིཎཽ སཱགརམདྷྱེ ཛཱལཾ པྲཀྵིཔནྟཽ དྲྀཥྚྭཱ ཏཱཝཝདཏ྄,
17 Jesu sì ké sí wọn wí pé, “Ẹ máa tọ̀ mí lẹ́yìn. Èmi yóò sì sọ yín di apẹja ènìyàn.”
ཡུཝཱཾ མམ པཤྩཱདཱགཙྪཏཾ, ཡུཝཱམཧཾ མནུཥྱདྷཱརིཎཽ ཀརིཥྱཱམི།
18 Ní kánkán wọ́n fi àwọ̀n wọn sílẹ̀, wọ́n sì tọ̀ Ọ́ lẹ́yìn.
ཏཏསྟཽ ཏཏྐྵཎམེཝ ཛཱལཱནི པརིཏྱཛྱ ཏསྱ པཤྩཱཏ྄ ཛགྨཏུཿ།
19 Bí Ó sì ti rìn síwájú díẹ̀, ní etí Òkun, Ó rí Jakọbu ọmọ Sebede àti Johanu arákùnrin rẹ̀ nínú ọkọ̀, wọ́n ń tún àwọ̀n wọn ṣe.
ཏཏཿ པརཾ ཏཏྶྠཱནཱཏ྄ ཀིཉྩིད྄ དཱུརཾ གཏྭཱ ས སིཝདཱིཔུཏྲཡཱཀཱུབ྄ ཏདྦྷྲཱཏྲྀཡོཧན྄ ཙ ཨིམཽ ནཽཀཱཡཱཾ ཛཱལཱནཱཾ ཛཱིརྞམུདྡྷཱརཡནྟཽ དྲྀཥྚྭཱ ཏཱཝཱཧཱུཡཏ྄།
20 Ó sì ké sí àwọn náà lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀, wọ́n fi Sebede baba wọn sílẹ̀ nínú ọkọ̀ pẹ̀lú àwọn alágbàṣe, wọ́n sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.
ཏཏསྟཽ ནཽཀཱཡཱཾ ཝེཏནབྷུགྦྷིཿ སཧིཏཾ སྭཔིཏརཾ ཝིཧཱཡ ཏཏྤཤྩཱདཱིཡཏུཿ།
21 Lẹ́yìn náà, Jesu àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wọ ìlú Kapernaumu, nígbà tí ó di òwúrọ̀ ọjọ́ ìsinmi, ó lọ sínú Sinagọgu, ó sì ń kọ́ni.
ཏཏཿ པརཾ ཀཕརྣཱཧཱུམྣཱམཀཾ ནགརམུཔསྠཱཡ ས ཝིཤྲཱམདིཝསེ བྷཛནགྲཧཾ པྲཝིཤྱ སམུཔདིདེཤ།
22 Ẹnu sì ya ìjọ ènìyàn nítorí ìkọ́ni rẹ̀, nítorí pé ó ń kọ́ni bí ẹni tí ó ní àṣẹ, kì í ṣe bí àwọn olùkọ́ òfin ṣe ń kọ́ àwọn ènìyàn.
ཏསྱོཔདེཤཱལློཀཱ ཨཱཤྩཪྻྱཾ མེནིརེ ཡཏཿ སོདྷྱཱཔཀཱཨིཝ ནོཔདིཤན྄ པྲབྷཱཝཝཱནིཝ པྲོཔདིདེཤ།
23 Ní àsìkò náà gan an ni ọkùnrin kan tí ó wà nínú Sinagọgu wọn, tí ó ní ẹ̀mí àìmọ́, bẹ̀rẹ̀ sí í kígbe wí pé,
ཨཔརཉྩ ཏསྨིན྄ བྷཛནགྲྀཧེ ཨཔཝིཏྲབྷཱུཏེན གྲསྟ ཨེཀོ མཱནུཥ ཨཱསཱིཏ྄། ས ཙཱིཏྴབྡཾ ཀྲྀཏྭཱ ཀཐཡཱཉྩཀེ
24 “Kí ni ìwọ ń wá lọ́dọ̀ wa, Jesu ti Nasareti? Ṣé ìwọ wá láti pa wá run ni? Èmí mọ ẹni tí ìwọ í ṣe; Ìwọ ní ẹni Mímọ́ Ọlọ́run!”
བྷོ ནཱསརཏཱིཡ ཡཱིཤོ ཏྭམསྨཱན྄ ཏྱཛ, ཏྭཡཱ སཧཱསྨཱཀཾ ཀཿ སམྦནྡྷཿ? ཏྭཾ ཀིམསྨཱན྄ ནཱཤཡིཏུཾ སམཱགཏཿ? ཏྭམཱིཤྭརསྱ པཝིཏྲལོཀ ཨིཏྱཧཾ ཛཱནཱམི།
25 Jesu si bá a wí, ó wí pé, “Pa ẹnu rẹ mọ́, kí ó sì jáde kúrò lára rẹ̀.”
ཏདཱ ཡཱིཤུསྟཾ ཏརྫཡིཏྭཱ ཛགཱད ཏཱུཥྞཱིཾ བྷཝ ཨིཏོ བཧིརྦྷཝ ཙ།
26 Ẹ̀mí àìmọ́ náà sì gbé e ṣánlẹ̀ lógèdèǹgbé, ó ké ní ohùn rara, ó sì jáde kúrò lára ọkùnrin náà.
ཏཏཿ སོ྅པཝིཏྲབྷཱུཏསྟཾ སམྤཱིཌྱ ཨཏྱུཙཻཤྩཱིཏྐྲྀཏྱ ནིརྫགཱམ།
27 Ẹnu sì ya àwọn ènìyàn, tó bẹ́ẹ̀ tí wọ́n fi ń sọ láàrín ara wọn ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀. Wọ́n béèrè pẹ̀lú ìgbóná ara, pé, “Kí ni èyí? Irú ẹ̀kọ́ tuntun wo ni èyí? Ó ń fi agbára pàṣẹ fún àwọn ẹ̀mí àìmọ́ pàápàá wọ́n sì gbọ́ tirẹ̀.”
ཏེནཻཝ སཪྻྭེ ཙམཏྐྲྀཏྱ པརསྤརཾ ཀཐཡཱཉྩཀྲིརེ, ཨཧོ ཀིམིདཾ? ཀཱིདྲྀཤོ྅ཡཾ ནཝྱ ཨུཔདེཤཿ? ཨནེན པྲབྷཱཝེནཱཔཝིཏྲབྷཱུཏེཥྭཱཛྙཱཔིཏེཥུ ཏེ ཏདཱཛྙཱནུཝརྟྟིནོ བྷཝནྟི།
28 Ìròyìn nípa rẹ̀ tàn ká gbogbo agbègbè Galili.
ཏདཱ ཏསྱ ཡཤོ གཱལཱིལཤྩཏུརྡིཀྶྠསཪྻྭདེཤཱན྄ ཝྱཱཔྣོཏ྄།
29 Nígbà tí wọn sì jáde kúrò nínú Sinagọgu, wọ́n lọ pẹ̀lú Jakọbu àti Johanu sí ilé Simoni àti Anderu.
ཨཔརཉྩ ཏེ བྷཛནགྲྀཧཱད྄ བཧི རྦྷཱུཏྭཱ ཡཱཀཱུབྱོཧནྦྷྱཱཾ སཧ ཤིམོན ཨཱནྡྲིཡསྱ ཙ ནིཝེཤནཾ པྲཝིཝིཤུཿ།
30 Ìyá ìyàwó Simoni tí ó dùbúlẹ̀ àìsàn ibà, wọ́n sì sọ fún Jesu nípa rẹ̀.
ཏདཱ པིཏརསྱ ཤྭཤྲཱུརྫྭརཔཱིཌིཏཱ ཤཡྻཱཡཱམཱསྟ ཨིཏི ཏེ ཏཾ ཛྷཊིཏི ཝིཛྙཱཔཡཱཉྩཀྲུཿ།
31 Ó sì tọ̀ ọ́ lọ, ó fà á lọ́wọ́, ó sì gbé e dìde; lójúkan náà ibà náà fi sílẹ̀, ó sì ń ṣe ìránṣẹ́ fún wọn.
ཏཏཿ ས ཨཱགཏྱ ཏསྱཱ ཧསྟཾ དྷྲྀཏྭཱ ཏཱམུདསྠཱཔཡཏ྄; ཏདཻཝ ཏཱཾ ཛྭརོ྅ཏྱཱཀྵཱིཏ྄ ཏཏཿ པརཾ སཱ ཏཱན྄ སིཥེཝེ།
32 Nígbà tí ó di àṣálẹ́, tí oòrùn wọ̀, wọ́n gbé gbogbo àwọn aláìsàn àti àwọn tó ni ẹ̀mí àìmọ́ tọ̀ ọ́ wá.
ཨཐཱསྟཾ གཏེ རཝཽ སནྡྷྱཱཀཱལེ སཏི ལོཀཱསྟཏྶམཱིཔཾ སཪྻྭཱན྄ རོགིཎོ བྷཱུཏདྷྲྀཏཱཾཤྩ སམཱནིནྱུཿ།
33 Gbogbo ìlú si péjọ ni ẹnu-ọ̀nà.
སཪྻྭེ ནཱགརིཀཱ ལོཀཱ དྭཱརི སཾམིལིཏཱཤྩ།
34 Jesu sì wo ọ̀pọ̀ tí wọ́n ní onírúurú ààrùn sàn. Bákan náà ni ó lé ọ̀pọ̀ ẹ̀mí àìmọ́ jáde. Ṣùgbọ́n kò sì jẹ́ kí àwọn ẹ̀mí àìmọ́ náà kí ó sọ̀rọ̀, nítorí tí wọ́n mọ ẹni tí òun í ṣe.
ཏཏཿ ས ནཱནཱཝིདྷརོགིཎོ བཧཱུན྄ མནུཛཱནརོགིཎཤྩཀཱར ཏཐཱ བཧཱུན྄ བྷཱུཏཱན྄ ཏྱཱཛཡཱཉྩཀཱར ཏཱན྄ བྷཱུཏཱན྄ ཀིམཔི ཝཱཀྱཾ ཝཀྟུཾ ནིཥིཥེདྷ ཙ ཡཏོཧེཏོསྟེ ཏམཛཱནན྄།
35 Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, kí ilẹ̀ tó mọ́, Jesu nìkan jáde lọ sí aginjù kan, láti lọ gbàdúrà.
ཨཔརཉྩ སོ྅ཏིཔྲཏྱཱུཥེ ཝསྟུཏསྟུ རཱཏྲིཤེཥེ སམུཏྠཱཡ བཧིརྦྷཱུཡ ནིརྫནཾ སྠཱནཾ གཏྭཱ ཏཏྲ པྲཱརྠཡཱཉྩཀྲེ།
36 Simoni àti àwọn ènìyàn rẹ̀ yòókù lọ láti wá a.
ཨནནྟརཾ ཤིམོན྄ ཏཏྶངྒིནཤྩ ཏསྱ པཤྩཱད྄ གཏཝནྟཿ།
37 Nígbà tí wọ́n sì rí I, wọ́n sọ fún wí pé, “Gbogbo ènìyàn ń wá ọ!”
ཏདུདྡེཤཾ པྲཱཔྱ ཏམཝདན྄ སཪྻྭེ ལོཀཱསྟྭཱཾ མྲྀགཡནྟེ།
38 Jesu sì dáhùn wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a lọ sí àwọn ìlú mìíràn, kí ń lè wàásù níbẹ̀ pẹ̀lú. Nítorí èyí ni èmi sá à ṣe wá.”
ཏདཱ སོ྅ཀཐཡཏ྄ ཨཱགཙྪཏ ཝཡཾ སམཱིཔསྠཱནི ནགརཱཎི ཡཱམཿ, ཡཏོ྅ཧཾ ཏཏྲ ཀཐཱཾ པྲཙཱརཡིཏུཾ བཧིརཱགམམ྄།
39 Nítorí náà, ó ń kiri gbogbo agbègbè Galili, ó ń wàásù nínú Sinagọgu. Ó sì ń lé àwọn ẹ̀mí àìmọ́ jáde.
ཨཐ ས ཏེཥཱཾ གཱལཱིལྤྲདེཤསྱ སཪྻྭེཥུ བྷཛནགྲྀཧེཥུ ཀཐཱཿ པྲཙཱརཡཱཉྩཀྲེ བྷཱུཏཱནཏྱཱཛཡཉྩ།
40 Ọkùnrin adẹ́tẹ̀ kan tọ̀ ọ́ wá, ó sì kúnlẹ̀ níwájú rẹ̀. Ó sì bẹ̀bẹ̀ fún ìmúláradá. Ó wí pé, “Bí ìwọ bá fẹ́, ìwọ lè mú mi láradá.”
ཨནནྟརམེཀཿ ཀུཥྛཱི སམཱགཏྱ ཏཏྶམྨུཁེ ཛཱནུཔཱཏཾ ཝིནཡཉྩ ཀྲྀཏྭཱ ཀཐིཏཝཱན྄ ཡདི བྷཝཱན྄ ཨིཙྪཏི ཏརྷི མཱཾ པརིཥྐརྟྟུཾ ཤཀྣོཏི།
41 Jesu kún fún àánú, ó na ọwọ́ rẹ̀, ó fi ọwọ́ rẹ̀ bà a, ó wí pé, “Èmí fẹ́. Di mímọ́.”
ཏཏཿ ཀྲྀཔཱལུ ཪྻཱིཤུཿ ཀརཽ པྲསཱཪྻྱ ཏཾ སྤཥྚྭཱ ཀཐཡཱམཱས
42 Lójúkan náà ẹ̀tẹ̀ náà fi sílẹ̀ lọ, ọkùnrin náà sì rí ìwòsàn.
མམེཙྪཱ ཝིདྱཏེ ཏྭཾ པརིཥྐྲྀཏོ བྷཝ། ཨེཏཏྐཐཱཡཱཿ ཀཐནམཱཏྲཱཏ྄ ས ཀུཥྛཱི རོགཱནྨུཀྟཿ པརིཥྐྲྀཏོ྅བྷཝཏ྄།
43 Jesu sì kìlọ̀ fún un gidigidi
ཏདཱ ས ཏཾ ཝིསྲྀཛན྄ གཱཌྷམཱདིཤྱ ཛགཱད
44 Ó wí pé, “Lọ fi ara rẹ̀ hàn àlùfáà Júù fún àyẹ̀wò. Ṣùgbọ́n má ṣe dúró sọ ohunkóhun fún ẹnikẹ́ni ní ọ̀nà. Mú ẹ̀bùn lọ́wọ́, èyí tí Mose pàṣẹ fún adẹ́tẹ̀ tí a mú láradá. Èyí tí í ṣe ẹ̀rí pé, ó ti rí ìwòsàn.”
སཱཝདྷཱནོ བྷཝ ཀཐཱམིམཱཾ ཀམཔི མཱ ཝད; སྭཱཏྨཱནཾ ཡཱཛཀཾ དརྴཡ, ལོཀེབྷྱཿ སྭཔརིཥྐྲྀཏེཿ པྲམཱཎདཱནཱཡ མཱུསཱནིརྞཱིཏཾ ཡདྡཱནཾ ཏདུཏྶྲྀཛསྭ ཙ།
45 Ṣùgbọ́n ó jáde lọ, ó bẹ̀rẹ̀ sí í pòkìkí, ó ń tan ìròyìn kálẹ̀. Nítorí èyí, Jesu kò sì le wọ ìlú ní gbangba mọ́, ṣùgbọ́n ó wà lẹ́yìn odi ìlú ní aginjù. Síbẹ̀, àwọn ènìyàn tọ̀ ọ́ wá láti ibi gbogbo.
ཀིནྟུ ས གཏྭཱ ཏཏ྄ ཀརྨྨ ཨིཏྠཾ ཝིསྟཱཪྻྱ པྲཙཱརཡིཏུཾ པྲཱརེབྷེ ཏེནཻཝ ཡཱིཤུཿ པུནཿ སཔྲཀཱཤཾ ནགརཾ པྲཝེཥྚུཾ ནཱཤཀྣོཏ྄ ཏཏོཧེཏོརྦཧིཿ ཀཱནནསྠཱནེ ཏསྱཽ; ཏཐཱཔི ཙཏུརྡྡིགྦྷྱོ ལོཀཱསྟསྱ སམཱིཔམཱཡཡུཿ།

< Mark 1 >