< Malachi 1 >

1 Ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀: ọ̀rọ̀ Olúwa sí Israẹli láti ẹnu Malaki.
Az Úr igéjének terhe Izráel ellen, Malakiás által.
2 “Èmí ti fẹ́ ẹ yín,” ni Olúwa wí. “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, ‘Báwo ni ìwọ ṣe fẹ́ wa?’ “Esau kì í ha ṣe arákùnrin Jakọbu bí?” ni Olúwa wí. “Síbẹ̀ èmi fẹ́ràn Jakọbu,
Szerettelek titeket, azt mondja az Úr, és azt mondjátok: Miben szerettél minket? Avagy nem atyjafia vala-é Ézsau Jákóbnak? azt mondja az Úr: Jákóbot pedig szerettem;
3 ṣùgbọ́n Esau ni mo kórìíra, mo ti sọ àwọn òkè ńlá rẹ̀ di aṣálẹ̀, mo sì fi ìní rẹ̀ fún àwọn akátá aginjù.”
Ézsaut ellenben gyűlöltem, és az ő hegyeit pusztává tettem, örökségét pedig pusztai sakálokévá.
4 Edomu lè wí pé, “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a run wá, àwa yóò padà wá, a ó sì tún ibùgbé náà kọ́.” Ṣùgbọ́n èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé: “Àwọn lè kọ́, ṣùgbọ́n èmi yóò wó palẹ̀. Wọn yóò sì pè wọ́n ní ilẹ̀ búburú, àwọn ènìyàn tí wọ́n máa ń wà ní ìbínú Olúwa.
Ha azt mondja Edom: Elpusztultunk; de térjünk meg és építsük fel a romladékokat: ezt mondja a Seregeknek Ura: Ők építenek, de én elrontom, és elnevezik őket istentelenség határának és oly népnek, a melyre örökké haragszik az Úr.
5 Ẹ̀yin yóò sì fi ojú yín rí i, ẹ̀yin yóò sì wí pé, ‘Títóbi ni Olúwa, títóbi rẹ̀ tayọ kọjá agbègbè Israẹli.’
És látják ezt a ti szemeitek, és magatok is mondjátok: Nagy az Úr az Izráel határa felett.
6 “Ọmọ a máa bu ọ̀wọ̀ fún baba rẹ̀, ọmọ ọ̀dọ̀ a sì máa bu ọlá fún olúwa rẹ̀. Ǹjẹ́ bí èmí bá jẹ́ baba, ọlá tí ó tọ́ sí mi ha dà? Bí èmi bá sì jẹ́ olúwa, ẹ̀rù tí ó tọ́ sí mi dà?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Ẹ̀yin ni, ẹ̀yin àlùfáà, ni ẹ ń gan orúkọ mi. “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, ‘Báwo ni àwa ṣe gan orúkọ rẹ?’
A fiú tiszteli atyját, a szolga is az ő urát. És ha én atya vagyok: hol az én tisztességem? És ha én úr vagyok, hol az én félelmem? azt mondja a Seregeknek Ura néktek, ti papok, a kik útáljátok az én nevemet, és ezt mondjátok: Mivel útáljuk a te nevedet?
7 “Ẹ̀yin gbé oúnjẹ àìmọ́ sí orí pẹpẹ mi. “Ẹ̀yin sì tún béèrè pé, ‘Báwo ni àwa ṣe ṣe àìmọ́ sí ọ?’ “Nípa sísọ pé tábìlì Olúwa di ẹ̀gàn.
Megfertéztetett kenyeret hoztok oltáromra, és azt mondjátok: Mivel fertéztetünk meg téged? Azzal, mikor azt gondoljátok, hogy az Úrnak asztala megvetni való.
8 Nígbà tí ẹ̀yin mú afọ́jú ẹran wá fún ìrúbọ, ṣé èyí kò ha burú bí? Nígbà tí ẹ̀yin fi amúnkùn ún àti aláìsàn ẹran rú ẹbọ, ṣé èyí kò ha burú gidigidi bí? Ẹ dán an wò, ẹ fi wọ́n rú ẹbọ sí àwọn baálẹ̀ yín! Ṣé inú rẹ̀ yóò dùn sí yín? Ṣé yóò gbà yín?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Hogyha vakot hoztok áldozatul: Nem bűn-é az? vagy ha sántát hoztok és bénát: nem bűn-é az? Vidd csak azt a te fejedelmednek: vajjon kedvvel fogad-é, avagy reád tekint-é? azt mondja a Seregeknek Ura.
9 “Ní ìsinsin yìí, ẹ bẹ Ọlọ́run kí ó ṣàánú fún wa. Ṣùgbọ́n pẹ̀lú irú àwọn ẹbọ wọ̀nyí láti ọwọ́ yín wá, ṣé yóò gbà yín?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Most azért engeszteljétek meg az Istennek orczáját, hogy könyörüljön rajtunk. Általatok van ez, elnézheti-é ezt néktek? azt mondja a Seregeknek Ura.
10 “Hó ò! Ẹnìkan ìbá jẹ́ wà láàrín yín ti yóò sé ìlẹ̀kùn tẹmpili, pé kí ẹ má ba à ṣe dá iná asán lórí pẹpẹ mi mọ́! Èmi kò ní inú dídùn sí i yín,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò gba ọrẹ kan lọ́wọ́ yín.
Vajha valaki közületek bezárná az ajtót, hiába ne tüzelnétek az én oltáromon! Nem telik kedvem bennetek, azt mondja a Seregeknek Ura; az ételáldozatot sem kedvelem a ti kezetekből!
11 Orúkọ mi yóò tóbi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, láti ìlà-oòrùn títí ó sì fi dé ìwọ̀-oòrùn. Ní ibi gbogbo ni a ó ti mú tùràrí àti ọrẹ mímọ́ wá fún orúkọ mi, nítorí orúkọ mi tóbi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Hiszen napkelettől fogva napnyugotig nagy az én nevem a pogányok között, és minden helyen tömjénnel áldoznak az én nevemnek és tiszta ételáldozattal! Bizony nagy az én nevem a pogányok között! azt mondja a Seregeknek Ura.
12 “Nítorí ẹ̀yin ti sọ ọ́ di àìmọ́, nínú èyí tí ẹ wí pé, ‘Tábìlì Olúwa di àìmọ́ àti èso rẹ̀,’ àní oúnjẹ rẹ̀ ni ohun ẹ̀gàn.
Ti pedig meggyalázzátok azt, mikor azt mondjátok: Az Úrnak asztala megvetni való, és annak jövedelme, eledele útálatos.
13 Ẹ̀yin wí pẹ̀lú pé, ‘Wò ó, irú àjàgà kín ni èyí!’ Ẹ̀yin sì yínmú sí i,” ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Nígbà tí ẹ̀yin sì mú èyí tí ó fi ara pa, arọ àti ọlọkùnrùn ẹran tí ẹ sì fi rú ẹbọ, Èmi o ha gba èyí lọ́wọ́ yín?” ni Olúwa wí.
És azt mondjátok: Ímé, mily fáradság! és ráfújtok, azt mondja a Seregeknek Ura; pedig a rablottat hozzátok, meg a sántát és betegest; ételáldozatot is hoztok, de hát kedves-é az a ti kezetekből? azt mondja az Úr.
14 “Ṣùgbọ́n ègún ni fún ẹlẹ́tàn náà, tí ó ni akọ nínú ọ̀wọ́ ẹran rẹ̀, tí ó sì ṣe ìlérí láti fi lélẹ̀ tí ó sì fi ẹran tó lábùkù rú ẹbọ sí Olúwa; nítorí ọba ńlá ni Èmi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “ẹ̀rù sì ni orúkọ mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
Átkozott pedig az álnok! Van ugyan a nyájában hím, és fogadást is tesz: mégis hitványnyal áldozik az Úrnak. Pedig nagy király vagyok én, azt mondja a Seregeknek Ura, és félelmetes az én nevem a pogányok között!

< Malachi 1 >