< Malachi 1 >

1 Ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀: ọ̀rọ̀ Olúwa sí Israẹli láti ẹnu Malaki.
Une révélation, la parole de Yahvé à Israël par Malachie.
2 “Èmí ti fẹ́ ẹ yín,” ni Olúwa wí. “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, ‘Báwo ni ìwọ ṣe fẹ́ wa?’ “Esau kì í ha ṣe arákùnrin Jakọbu bí?” ni Olúwa wí. “Síbẹ̀ èmi fẹ́ràn Jakọbu,
« Je t'ai aimé », dit Yahvé. Pourtant, vous dites: « Comment nous avez-vous aimés? » « Esaü n'était-il pas le frère de Jacob? dit Yahvé, « J'ai aimé Jacob,
3 ṣùgbọ́n Esau ni mo kórìíra, mo ti sọ àwọn òkè ńlá rẹ̀ di aṣálẹ̀, mo sì fi ìní rẹ̀ fún àwọn akátá aginjù.”
mais j'ai haï Esaü, j'ai fait de ses montagnes un désert, et j'ai donné son héritage aux chacals du désert. »
4 Edomu lè wí pé, “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a run wá, àwa yóò padà wá, a ó sì tún ibùgbé náà kọ́.” Ṣùgbọ́n èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé: “Àwọn lè kọ́, ṣùgbọ́n èmi yóò wó palẹ̀. Wọn yóò sì pè wọ́n ní ilẹ̀ búburú, àwọn ènìyàn tí wọ́n máa ń wà ní ìbínú Olúwa.
Alors qu'Édom dit: « Nous sommes abattus, mais nous reviendrons et nous rebâtirons les ruines », Yahvé des armées dit: « Ils bâtiront, mais je les renverserai; et on les appellera « le pays des méchants », le peuple contre lequel Yahvé manifeste sa colère à jamais. »
5 Ẹ̀yin yóò sì fi ojú yín rí i, ẹ̀yin yóò sì wí pé, ‘Títóbi ni Olúwa, títóbi rẹ̀ tayọ kọjá agbègbè Israẹli.’
Vos yeux verront et vous direz: « Yahvé est grand, même au-delà de la frontière d'Israël. »
6 “Ọmọ a máa bu ọ̀wọ̀ fún baba rẹ̀, ọmọ ọ̀dọ̀ a sì máa bu ọlá fún olúwa rẹ̀. Ǹjẹ́ bí èmí bá jẹ́ baba, ọlá tí ó tọ́ sí mi ha dà? Bí èmi bá sì jẹ́ olúwa, ẹ̀rù tí ó tọ́ sí mi dà?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Ẹ̀yin ni, ẹ̀yin àlùfáà, ni ẹ ń gan orúkọ mi. “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, ‘Báwo ni àwa ṣe gan orúkọ rẹ?’
« Un fils honore son père, et un serviteur son maître. Si je suis un père, où est mon honneur? Et si je suis un maître, où est le respect qui m'est dû? » dit Yahvé des armées à vous, prêtres, qui méprisez mon nom. Vous dites: « Comment avons-nous méprisé ton nom? »
7 “Ẹ̀yin gbé oúnjẹ àìmọ́ sí orí pẹpẹ mi. “Ẹ̀yin sì tún béèrè pé, ‘Báwo ni àwa ṣe ṣe àìmọ́ sí ọ?’ “Nípa sísọ pé tábìlì Olúwa di ẹ̀gàn.
Vous offrez sur mon autel des pains souillés. Vous dites: Comment t'avons-nous pollué? En cela, vous dites: La table de Yahvé est méprisable.
8 Nígbà tí ẹ̀yin mú afọ́jú ẹran wá fún ìrúbọ, ṣé èyí kò ha burú bí? Nígbà tí ẹ̀yin fi amúnkùn ún àti aláìsàn ẹran rú ẹbọ, ṣé èyí kò ha burú gidigidi bí? Ẹ dán an wò, ẹ fi wọ́n rú ẹbọ sí àwọn baálẹ̀ yín! Ṣé inú rẹ̀ yóò dùn sí yín? Ṣé yóò gbà yín?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Quand vous offrez un aveugle en sacrifice, n'est-ce pas un mal? Et quand vous offrez en sacrifice des boiteux et des malades, n'est-ce pas un mal? Présentez-le maintenant à votre gouverneur! Sera-t-il satisfait de vous? Ou bien acceptera-t-il votre personne? » dit Yahvé des Armées.
9 “Ní ìsinsin yìí, ẹ bẹ Ọlọ́run kí ó ṣàánú fún wa. Ṣùgbọ́n pẹ̀lú irú àwọn ẹbọ wọ̀nyí láti ọwọ́ yín wá, ṣé yóò gbà yín?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
« Implorez maintenant la faveur de Dieu, afin qu'il nous fasse grâce. Avec cela, acceptera-t-il l'un de vous? » dit Yahvé des Armées.
10 “Hó ò! Ẹnìkan ìbá jẹ́ wà láàrín yín ti yóò sé ìlẹ̀kùn tẹmpili, pé kí ẹ má ba à ṣe dá iná asán lórí pẹpẹ mi mọ́! Èmi kò ní inú dídùn sí i yín,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò gba ọrẹ kan lọ́wọ́ yín.
« Oh, s'il y en avait un parmi vous qui fermât les portes, pour que vous n'allumiez pas en vain du feu sur mon autel! Je ne prends aucun plaisir en vous, dit Yahvé des armées, et je n'accepterai pas d'offrande de votre part.
11 Orúkọ mi yóò tóbi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, láti ìlà-oòrùn títí ó sì fi dé ìwọ̀-oòrùn. Ní ibi gbogbo ni a ó ti mú tùràrí àti ọrẹ mímọ́ wá fún orúkọ mi, nítorí orúkọ mi tóbi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Car, depuis le lever du soleil jusqu'à son coucher, mon nom est grand parmi les nations, et en tout lieu on offre à mon nom de l'encens et une offrande pure, car mon nom est grand parmi les nations, dit l'Éternel des armées.
12 “Nítorí ẹ̀yin ti sọ ọ́ di àìmọ́, nínú èyí tí ẹ wí pé, ‘Tábìlì Olúwa di àìmọ́ àti èso rẹ̀,’ àní oúnjẹ rẹ̀ ni ohun ẹ̀gàn.
« Mais vous le profanez en disant: 'La table de l'Éternel est souillée, et son fruit, sa nourriture même, est méprisable'.
13 Ẹ̀yin wí pẹ̀lú pé, ‘Wò ó, irú àjàgà kín ni èyí!’ Ẹ̀yin sì yínmú sí i,” ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Nígbà tí ẹ̀yin sì mú èyí tí ó fi ara pa, arọ àti ọlọkùnrùn ẹran tí ẹ sì fi rú ẹbọ, Èmi o ha gba èyí lọ́wọ́ yín?” ni Olúwa wí.
Vous dites aussi: 'Voici, quelle fatigue c'est!'. Et vous l'avez reniflé, dit Yahvé des Armées, et vous avez apporté ce qui a été pris par violence, le boiteux et le malade; c'est ainsi que vous apportez l'offrande. Dois-je accepter cela de ta main? dit Yahvé.
14 “Ṣùgbọ́n ègún ni fún ẹlẹ́tàn náà, tí ó ni akọ nínú ọ̀wọ́ ẹran rẹ̀, tí ó sì ṣe ìlérí láti fi lélẹ̀ tí ó sì fi ẹran tó lábùkù rú ẹbọ sí Olúwa; nítorí ọba ńlá ni Èmi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “ẹ̀rù sì ni orúkọ mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
« Mais est maudit le trompeur qui a dans son troupeau un mâle, et qui fait des vœux et sacrifie à l'Éternel une chose défectueuse; car je suis un grand Roi, dit Yahvé des armées, et mon nom est redoutable parmi les nations. »

< Malachi 1 >