< Malachi 4 >

1 “Dájúdájú, ọjọ́ náà ń bọ̀; tí yóò máa jó bi iná ìléru. Gbogbo àwọn agbéraga, àti gbogbo àwọn olùṣe búburú yóò dàbí àgékù koríko: ọjọ́ náà tí ń bọ̀ yóò si jó wọn run,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Ti ki yóò fi kù gbòǹgbò kan tàbí ẹ̀ka kan fún wọn.
Ta te mea, nana, kei te haere mai te ra, e ngiha ai ano he oumu; na, ko te hunga whakakake katoa, me te hunga katoa e mahi ana i te kino hei kakau witi ratou: a ka tahuna e te ra meake nei puta, e ai ta Ihowa o nga mano, e kore ano he pakiaka, he manga e mahue ki a ratou.
2 Ṣùgbọ́n fún ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù orúkọ mi, oòrùn òdodo yóò yọ, pẹ̀lú ìmúláradá ni ìyẹ́ apá rẹ̀. Ẹ̀yin yóò sì jáde lọ, ẹ̀yin yóò sì máa fò fún ayọ̀ bi àwọn ẹgbọrọ màlúù tí a tú sílẹ̀ lórí ìso.
Ki a koutou ia e wehi na i toku ingoa ka ara ake te ra o te tika, he whakaora mate hoki i runga i ona parirau; a ka puta mai koutou, ka tupekepeke ano he kuao kau no te turanga kau.
3 Ẹ̀yin yóò sì tẹ àwọn ènìyàn búburú mọ́lẹ̀: nítorí wọn yóò di eérú lábẹ́ àtẹ́lẹsẹ̀ yín, ní ọjọ́ náà tí èmi yóò ṣe nǹkan wọ̀nyí,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Ka takatakahia ano e koutou te hunga kino; ka rite hoki ratou ki nga pungarehu i raro i nga kapu o o koutou waewae i te ra e mahi ai ahau, e ai ta Ihowa o nga mano.
4 “Ẹ rántí òfin Mose ìránṣẹ́ mi, àwọn ìlànà àti òfin èyí tí mo fún un ní Horebu fún gbogbo Israẹli.”
Kia mahara ki te ture a taku pononga, a Mohi, ki taku i whakahau ai ki a ia i Horepa, he mea mo Iharaira katoa, ki nga tikanga, ki nga whakaritenga.
5 “Wò ó, èmi yóò rán wòlíì Elijah sí i yín, ki ọjọ́ ńlá, ọjọ́ ẹ̀rù Olúwa to dé.
Nana, ka unga atu e ahau a Iraia poropiti ki a koutou i mua i te taenga mai o te ra nui o Ihowa, o te ra whakamataku.
6 Òun yóò sì pa ọkàn àwọn baba dà sí ti àwọn ọmọ, àti ọkàn àwọn ọmọ sì ti àwọn baba wọn, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, èmi yóò wá, èmi yóò sì fi ilẹ̀ náà gégùn.”
A ka tahuri i a ia nga ngakau o nga matua ki nga tamariki, me nga ngakau o nga tamariki ki o ratou matua; kei haere atu ahau, kei patu i te whenua ki te kanga.

< Malachi 4 >