< Malachi 4 >
1 “Dájúdájú, ọjọ́ náà ń bọ̀; tí yóò máa jó bi iná ìléru. Gbogbo àwọn agbéraga, àti gbogbo àwọn olùṣe búburú yóò dàbí àgékù koríko: ọjọ́ náà tí ń bọ̀ yóò si jó wọn run,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Ti ki yóò fi kù gbòǹgbò kan tàbí ẹ̀ka kan fún wọn.
NO ka mea, aia hoi! ke hele mai la ka la e enaena ana me he umu ahi la, Ilaila o ka poe hookiekie a pau, A me ka poe hana ino, he mauu lakou: A e hoopau ua la la e hiki mai ana ia lakou, Wahi a Iehova o na kaua, A e waiho ole ia i aa no lakou, aole hoi lala.
2 Ṣùgbọ́n fún ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù orúkọ mi, oòrùn òdodo yóò yọ, pẹ̀lú ìmúláradá ni ìyẹ́ apá rẹ̀. Ẹ̀yin yóò sì jáde lọ, ẹ̀yin yóò sì máa fò fún ayọ̀ bi àwọn ẹgbọrọ màlúù tí a tú sílẹ̀ lórí ìso.
Aka, no oukou ka poe weliweli i ko'u inoa, E puka mai ana ka La o ka pono, Me ka mea hoola iloko o kona mau eheu; A e hele aku oukou, a e lele olioli, E like me na bipi keiki i kupaluia.
3 Ẹ̀yin yóò sì tẹ àwọn ènìyàn búburú mọ́lẹ̀: nítorí wọn yóò di eérú lábẹ́ àtẹ́lẹsẹ̀ yín, ní ọjọ́ náà tí èmi yóò ṣe nǹkan wọ̀nyí,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
A e hehi iho oukou i ka poe aia; A e lilo lakou i lehu malalo iho o ko oukou mau wawae, I ka la a'u e hana'i i keia, wahi a Iehova o na kaua.
4 “Ẹ rántí òfin Mose ìránṣẹ́ mi, àwọn ìlànà àti òfin èyí tí mo fún un ní Horebu fún gbogbo Israẹli.”
E hoomanao oukou i ke kanawai o Mose, O kuu kauwa, a'u i haawi aku ai ia ia ma Horeba, A i ka Iseraela a pau, me na kauoha, a me na olelo hoopono.
5 “Wò ó, èmi yóò rán wòlíì Elijah sí i yín, ki ọjọ́ ńlá, ọjọ́ ẹ̀rù Olúwa to dé.
Aia hoi, e hoouna aku au ia Elia ke kaula io oukou la, Mamua mai o ka hiki ana o ua la nui weliweli la o Iehova.
6 Òun yóò sì pa ọkàn àwọn baba dà sí ti àwọn ọmọ, àti ọkàn àwọn ọmọ sì ti àwọn baba wọn, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, èmi yóò wá, èmi yóò sì fi ilẹ̀ náà gégùn.”
A e hoohuli ae oia i ka naau o na makua i na keiki, A me ka naau o na keiki i na makua, O hele aku paha auanei au, A hahau i ka honua i ka hoino ana. KA HOPENA O KE KAUOHA KAHIKO.