< Malachi 4 >

1 “Dájúdájú, ọjọ́ náà ń bọ̀; tí yóò máa jó bi iná ìléru. Gbogbo àwọn agbéraga, àti gbogbo àwọn olùṣe búburú yóò dàbí àgékù koríko: ọjọ́ náà tí ń bọ̀ yóò si jó wọn run,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Ti ki yóò fi kù gbòǹgbò kan tàbí ẹ̀ka kan fún wọn.
Thi se, Dagen kommer, luende som en Ovn; og alle de frække og alle, som øver Gudløshed, skal blive som Strå, og Dagen, som kommer, skal lade dem gå op i Luer, siger Hærskarers HERRE, så der ikke levnes Rod eller Gren at dem.
2 Ṣùgbọ́n fún ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù orúkọ mi, oòrùn òdodo yóò yọ, pẹ̀lú ìmúláradá ni ìyẹ́ apá rẹ̀. Ẹ̀yin yóò sì jáde lọ, ẹ̀yin yóò sì máa fò fún ayọ̀ bi àwọn ẹgbọrọ màlúù tí a tú sílẹ̀ lórí ìso.
Men for eder, som frygter mit Navn, skal Retfærds Sol opgå med Lægedom under sine Vinger, og I skal gå ud og boltre eder som Kalve, der kommer fra Stalden,
3 Ẹ̀yin yóò sì tẹ àwọn ènìyàn búburú mọ́lẹ̀: nítorí wọn yóò di eérú lábẹ́ àtẹ́lẹsẹ̀ yín, ní ọjọ́ náà tí èmi yóò ṣe nǹkan wọ̀nyí,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
og trampe de gudløse ned; thi de skal blive til Støv under eders Fodsåler, den bag jeg griber ind, siger Hærskarers HERRE.
4 “Ẹ rántí òfin Mose ìránṣẹ́ mi, àwọn ìlànà àti òfin èyí tí mo fún un ní Horebu fún gbogbo Israẹli.”
Kom min Tjener Moses's Lov i Hu, hvem jeg pålagde Vedtægter og Lovbud om alt Israel på Horeb.
5 “Wò ó, èmi yóò rán wòlíì Elijah sí i yín, ki ọjọ́ ńlá, ọjọ́ ẹ̀rù Olúwa to dé.
Se, jeg sender eder Profeten Elias, før HERRENs store og frygtelige Dag kommer.
6 Òun yóò sì pa ọkàn àwọn baba dà sí ti àwọn ọmọ, àti ọkàn àwọn ọmọ sì ti àwọn baba wọn, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, èmi yóò wá, èmi yóò sì fi ilẹ̀ náà gégùn.”
Han skal vende Fædrenes Hjerte til Sønnerne og Sønnernes til Fædrene, at jeg ikke skal komme og slå Landet med Band.

< Malachi 4 >