< Malachi 3 >

1 “Wò ó, Èmi yóò ran ìránṣẹ́ mi, yóò tún ọ̀nà ṣe ṣáájú mi. Nígbà náà ni Olúwa, tí ẹ̀yin ń wa, yóò dé ni òjijì sí tẹmpili rẹ̀; àní oníṣẹ́ májẹ̀mú náà, tí inú yín dùn sí, yóò dé,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Se, jag skall sända ut min ängel, och han skall bereda väg för mig. Och med hast skall han komma till sitt tempel, den Herre, som I åstunden, ja, förbundets ängel, som I begären, se, han kommer, säger HERREN Sebaot.
2 Ṣùgbọ́n ta ni o lè fi ara da ọjọ́ dídé rẹ̀? Ta ni yóò sì dúró nígbà tí ó bá fi ara hàn? Nítorí òun yóò dàbí iná ẹni tí ń da fàdákà àti bi ọṣẹ alágbàfọ̀.
Men vem kan uthärda hans tillkommelses dag, och vem kan bestå, när han uppenbarar sig? Ty han skall vara såsom en guldsmeds eld och såsom valkares såpa.
3 Òun yóò sì jókòó bí ẹni tí n yọ́, tí ó sì ń da fàdákà; yóò wẹ àwọn ọmọ Lefi mọ́, yóò sì tún wọn dàbí wúrà àti fàdákà, kí wọn bá a lè mú ọrẹ òdodo wá fún Olúwa,
Och han skall sätta sig ned och smälta silvret och rena det; han skall rena Levi söner och luttra dem såsom guld och silver; och sedan skola de frambära åt HERREN offergåvor i rättfärdighet.
4 nígbà náà ni ọrẹ Juda àti ti Jerusalẹmu yóò jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ti ọjọ́ àtijọ́, àti gẹ́gẹ́ bí ọdún ìgbàanì.
Och Juda offergåvor och Jerusalems skola då behaga HERREN väl likasom i forna dagar och i förgångna år.
5 “Èmi ó sì súnmọ́ yin fún ìdájọ́. Èmi yóò sì yára ṣe ẹlẹ́rìí sí àwọn oṣó, sí àwọn panṣágà, sí àwọn abúra èké, àti àwọn tí ó fi ọ̀yà alágbàṣe pọn wọn lójú, àti àwọn tí ó ni àwọn opó àti àwọn aláìní baba lára, àti sí ẹni tí kò jẹ́ kí àjèjì rí ìdájọ́ òdodo gbà, tí wọn kò sì bẹ̀rù mi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Ja, jag skall komma till eder för att hålla dom, och jag skall vara ett snarfärdigt vittne mot trollkarlar, äktenskapsbrytare och menedare, så ock mot dem som förhålla dagakarlen hans lön eller förtrycka änkan och den faderlöse eller vränga rätten för främlingen, men icke frukta mig, säger HERREN Sebaot.
6 “Èmi Olúwa kò yípadà. Nítorí náà ni a kò ṣe run ẹ̀yin ọmọ Jakọbu.
Ty jag, HERREN, har icke förändrats, och I, Jakobs barn, haven icke heller hört upp:
7 Láti ọjọ́ àwọn baba ńlá yín wá ni ẹ̀yin tilẹ̀ ti kọ ẹ̀yìn sí ìlànà mi, tí ẹ kò sì pa wọ́n mọ́. Ẹ padà wá sí ọ̀dọ̀ mi, Èmi yóò sì padà sí ọ̀dọ̀ yín,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, ‘Báwo ni àwa yóò ṣe padà?’
allt ifrån edra fäders dagar haven I vikit av ifrån mina stadgar och icke hållit dem Vänden om till mig, så vill jag vända om till eder, säger HERREN Sebaot. Nu frågen I: "Varutinnan skola vi vända om?"
8 “Ènìyàn yóò ha ja Ọlọ́run ni olè bí? Síbẹ̀ ẹ̀yin ti jà mí ní olè. “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, ‘Báwo ni àwa ṣe jà ọ́ ní olè?’ “Nípa ìdámẹ́wàá àti ọrẹ.
Menen I då, att en människa får röva från Gud? Ty I röven ju från mig. Åter frågen I: "På vad sätt hava vi rövat från dig?" Jo, i fråga om tionden och offergärden.
9 Ríré ni a ó fi yín ré: gbogbo orílẹ̀-èdè yìí, nítorí ẹ̀yin ti jà mi lólè.
Förbannelse har drabbat eder, men ändå röven I från mig, så många I ären.
10 Ẹ mú gbogbo ìdámẹ́wàá wá sí ilé ìṣúra, kí oúnjẹ bá à lè wà ní ilé mi, ẹ fi èyí dán mi wò,” ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “kí ẹ sì wò bí èmi kò bá ní sí àwọn fèrèsé ọ̀run fún yin, kí èmi sì tú ìbùkún àkúnwọ́sílẹ̀ jáde fún yín, tó bẹ́ẹ̀ tí kì yóò sì ààyè láti gbà á.
Fören full tionde till förrådshuset, så att i mitt hus finnes mat, och pröven så, hurudan jag sedan bliver, säger HERREN Sebaot. Förvisso skall jag då öppna himmelens fönster över eder och utgjuta över eder riklig välsignelse.
11 Èmi yóò sì bá kòkòrò ajẹnirun wí nítorí yín, òun kò sì ni run èso ilẹ̀ yín, bẹ́ẹ̀ ni àjàrà inú oko yín kò ní rẹ̀ dànù,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Och jag skall näpsa gräshopporna för eder, så att de icke mer fördärva eder frukt på marken; ej heller skola edra vinträd mer slå fel på fältet, säger HERREN Sebaot.
12 “Nígbà náà ni gbogbo orílẹ̀-èdè yóò sì pè yín ni alábùkún fún, nítorí tiyín yóò jẹ́ ilẹ̀ tí ó wu ni,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Och alla folk skola prisa eder sälla, ty edert land skall då vara ljuvligt, säger HERREN Sebaot.
13 “Ẹ̀yin ti sọ ọ̀rọ̀ líle sí mi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Síbẹ̀ ẹ̀yin béèrè pé, ‘Ọ̀rọ̀ kín ni àwa sọ sí ọ?’
I haven talat hårda ord mot mig, säger HERREN. Nu frågen I: "Vad hava vi då med varandra talat mot dig?"
14 “Ẹ̀yin ti wí pé, ‘Asán ni láti sin Ọlọ́run. Kí ni àwa jẹ ní èrè, nígbà tí àwa ti pa ìlànà rẹ mọ́, tí àwa sì ń rìn kiri bí ẹni tí ń ṣọ̀fọ̀ ní iwájú Olúwa àwọn ọmọ-ogun?
I haven sagt: "Det är fåfängt att tjäna Gud. Eller vad vinning hava vi därav att vi hålla, vad han har bjudit oss hålla, och därav att vi gå i sorgdräkt inför HERREN Sebaot?
15 Ṣùgbọ́n ní ìsinsin yìí àwa pé agbéraga ni alábùkún fún. Ní òtítọ́ ni àwọn ti ń ṣe búburú ń gbèrú sí i, kódà àwọn ti ó dán Ọlọ́run wò ni a dá sí.’”
Nej, de fräcka vilja vi nu prisa sälla; ty de som göra, vad ogudaktigt är, bliva upprättade, de gå fria, huru de än fresta Gud."
16 Nígbà náà ni àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa ń ba ara wọn sọ̀rọ̀, Olúwa sì tẹ́tí sí i, ó sì gbọ́. A sì kọ ìwé ìrántí kan níwájú rẹ̀, fún àwọn tí o bẹ̀rù Olúwa, tiwọn sì bọ̀wọ̀ fún orúkọ rẹ̀.
Men därunder hava också de som frukta HERREN talat med varandra; och HERREN har aktat på dem och hört dem, och en minnesbok har blivit skriven inför hans ansikte till åminnelse av dessa som frukta HERREN och tänka på hans namn.
17 “Wọn yóò sì jẹ́ tèmi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “ni ọjọ́ náà, tí èmi ó dá; èmi yóò sì da wọ́n sí gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí máa ń dá ọmọ rẹ̀ tí yóò sìn ín sí.
Och dessa, säger HERREN Sebaot, skall jag hava såsom min egendom på den dag, då jag utför mitt verk; och jag skall skona dem, såsom en fader skonar sin son, som tjänar honom.
18 Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò rí ìyàtọ̀, ìyàtọ̀ láàrín olódodo àti ẹni búburú, láàrín ẹni tí ń sìn Ọlọ́run, àti ẹni tí kò sìn ín.
Och I skolen då åter få se, vilken skillnad det är mellan den rättfärdige och den ogudaktige, mellan den som tjänar Gud och den som icke tjänar honom.

< Malachi 3 >