< Malachi 3 >
1 “Wò ó, Èmi yóò ran ìránṣẹ́ mi, yóò tún ọ̀nà ṣe ṣáájú mi. Nígbà náà ni Olúwa, tí ẹ̀yin ń wa, yóò dé ni òjijì sí tẹmpili rẹ̀; àní oníṣẹ́ májẹ̀mú náà, tí inú yín dùn sí, yóò dé,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Íme, én elküldöm követemet, hogy utat törjön előttem: és hirtelen eljő templomához az Úr, a kit kivántok, és a szövetség angyala, a kit akartok, íme eljön, mondja az Örökkévaló, a seregek ura.
2 Ṣùgbọ́n ta ni o lè fi ara da ọjọ́ dídé rẹ̀? Ta ni yóò sì dúró nígbà tí ó bá fi ara hàn? Nítorí òun yóò dàbí iná ẹni tí ń da fàdákà àti bi ọṣẹ alágbàfọ̀.
De ki birja eljöttének napját és ki az, a ki megállhat megjelenésekor? Mert ő olyan, mint az olvasztónak a tüze, vagy mint a ruhamosók lúgja.
3 Òun yóò sì jókòó bí ẹni tí n yọ́, tí ó sì ń da fàdákà; yóò wẹ àwọn ọmọ Lefi mọ́, yóò sì tún wọn dàbí wúrà àti fàdákà, kí wọn bá a lè mú ọrẹ òdodo wá fún Olúwa,
És ott ül – olvasztva és tisztítva ezüstöt – és megtisztítja a Lévi fiait, és megválasztja őket, mint az aranyat s az ezüstöt, hogy legyenek az Örökkévalónak igazsággal áldozatot hozók.
4 nígbà náà ni ọrẹ Juda àti ti Jerusalẹmu yóò jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ti ọjọ́ àtijọ́, àti gẹ́gẹ́ bí ọdún ìgbàanì.
Akkor kellemes lesz az Örökkévalónak Jehúdának és Jeruzsálemnek áldozata, mint az őskor napjaiban és mint az előbbi években.
5 “Èmi ó sì súnmọ́ yin fún ìdájọ́. Èmi yóò sì yára ṣe ẹlẹ́rìí sí àwọn oṣó, sí àwọn panṣágà, sí àwọn abúra èké, àti àwọn tí ó fi ọ̀yà alágbàṣe pọn wọn lójú, àti àwọn tí ó ni àwọn opó àti àwọn aláìní baba lára, àti sí ẹni tí kò jẹ́ kí àjèjì rí ìdájọ́ òdodo gbà, tí wọn kò sì bẹ̀rù mi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
És közeledem hozzátok az ítéletre, és siető tanu leszek a varázsolók ellen és a házasságtörők ellen és a hazugúl esküdők ellen, és azok ellen, kik nyomorgatják a bérest az ő bérében, az özvegyet és az árvát, és jogától elhajlítják a jövevényt, és nem félnek engem, mondja az Örökkévaló, a seregek ura.
6 “Èmi Olúwa kò yípadà. Nítorí náà ni a kò ṣe run ẹ̀yin ọmọ Jakọbu.
Mert én, az Örökkévaló, nem változtam meg, sem ti, Jákób fiai nem enyésztétek el.
7 Láti ọjọ́ àwọn baba ńlá yín wá ni ẹ̀yin tilẹ̀ ti kọ ẹ̀yìn sí ìlànà mi, tí ẹ kò sì pa wọ́n mọ́. Ẹ padà wá sí ọ̀dọ̀ mi, Èmi yóò sì padà sí ọ̀dọ̀ yín,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, ‘Báwo ni àwa yóò ṣe padà?’
seitek napjaitól fogva eltértetek törvényeimtől és nem őriztétek meg, térjetek vissza hozzám, hogy visszatérhessek hozzátok, mondja az Örökkévaló, a seregek ura. És ti mondjátok: mivel térjünk vissza?
8 “Ènìyàn yóò ha ja Ọlọ́run ni olè bí? Síbẹ̀ ẹ̀yin ti jà mí ní olè. “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, ‘Báwo ni àwa ṣe jà ọ́ ní olè?’ “Nípa ìdámẹ́wàá àti ọrẹ.
Megcsal-e ember Istent, hogy ti engem megcsaltok? És ti mondjátok: mivel csaltunk meg téged? A tizeddel és az adománynyal.
9 Ríré ni a ó fi yín ré: gbogbo orílẹ̀-èdè yìí, nítorí ẹ̀yin ti jà mi lólè.
Az átokkal vagytok megátkozva, és engem csaltok meg ti, az egész nemzet!
10 Ẹ mú gbogbo ìdámẹ́wàá wá sí ilé ìṣúra, kí oúnjẹ bá à lè wà ní ilé mi, ẹ fi èyí dán mi wò,” ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “kí ẹ sì wò bí èmi kò bá ní sí àwọn fèrèsé ọ̀run fún yin, kí èmi sì tú ìbùkún àkúnwọ́sílẹ̀ jáde fún yín, tó bẹ́ẹ̀ tí kì yóò sì ààyè láti gbà á.
Hozzátok el az egész tizedet a kincstár házába, hogy eleség legyen házamban, és próbáljatok csak meg engem ezzel, mondja az Örökkévaló a seregek ura, nem nyitom-e meg nektek az égnek ablakrácsait, hogy kiöntsek nektek áldást, az elégnél is többet.
11 Èmi yóò sì bá kòkòrò ajẹnirun wí nítorí yín, òun kò sì ni run èso ilẹ̀ yín, bẹ́ẹ̀ ni àjàrà inú oko yín kò ní rẹ̀ dànù,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
S megszidom értetek a faló sáskát, hogy meg ne rontsa néktek a földnek gyümölcsét, és terméketlen ne legyen nektek a szőlőtő a mezőben, mondja az Örökkévaló, a seregek ura.
12 “Nígbà náà ni gbogbo orílẹ̀-èdè yóò sì pè yín ni alábùkún fún, nítorí tiyín yóò jẹ́ ilẹ̀ tí ó wu ni,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
És boldognak mondanak titeket mind a nemzetek, mert kedvelt ország lesztek ti, mondja az Örökkévaló, a seregek ura.
13 “Ẹ̀yin ti sọ ọ̀rọ̀ líle sí mi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Síbẹ̀ ẹ̀yin béèrè pé, ‘Ọ̀rọ̀ kín ni àwa sọ sí ọ?’
Erősek voltak ellenem beszédeitek, mondja az Örökkévaló. És mondjátok: mit beszéltünk egymással ellened?
14 “Ẹ̀yin ti wí pé, ‘Asán ni láti sin Ọlọ́run. Kí ni àwa jẹ ní èrè, nígbà tí àwa ti pa ìlànà rẹ mọ́, tí àwa sì ń rìn kiri bí ẹni tí ń ṣọ̀fọ̀ ní iwájú Olúwa àwọn ọmọ-ogun?
Azt mondtátok: hiábavaló dolog Istent szolgálni: és mi a haszna, hogy megőriztük őrizetét, s hogy elszomorodva jártunk az Örökkévaló, a seregek ura miatt?
15 Ṣùgbọ́n ní ìsinsin yìí àwa pé agbéraga ni alábùkún fún. Ní òtítọ́ ni àwọn ti ń ṣe búburú ń gbèrú sí i, kódà àwọn ti ó dán Ọlọ́run wò ni a dá sí.’”
Most pedig boldogoknak mondjuk mi a kevélyeket, fel is épültek a gonoszság cselekvői, meg is próbálták az Istent és megmenekültek.
16 Nígbà náà ni àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa ń ba ara wọn sọ̀rọ̀, Olúwa sì tẹ́tí sí i, ó sì gbọ́. A sì kọ ìwé ìrántí kan níwájú rẹ̀, fún àwọn tí o bẹ̀rù Olúwa, tiwọn sì bọ̀wọ̀ fún orúkọ rẹ̀.
Akkor egymással beszéltek az Istenfélők, kiki a társával, az Örökkévaló pedig figyelt s meghallotta, és megíratott az emlékezet könyve őelőtte az Istenfélők számára és azok számára, kik a nevét tekintik.
17 “Wọn yóò sì jẹ́ tèmi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “ni ọjọ́ náà, tí èmi ó dá; èmi yóò sì da wọ́n sí gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí máa ń dá ọmọ rẹ̀ tí yóò sìn ín sí.
És lesznek nékem, mondja az Örökkévaló, a seregek ura, azon napon, melyet én készítek, kiváló tulajdonul, hogy megszánom őket, amint megszánja valaki a fiát, aki őt szolgálja.
18 Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò rí ìyàtọ̀, ìyàtọ̀ láàrín olódodo àti ẹni búburú, láàrín ẹni tí ń sìn Ọlọ́run, àti ẹni tí kò sìn ín.
És majd újra látjátok, mi különbség van az igaz meg a gonosz között, az Istent szolgáló meg aközött, ki őt nem szolgálta.