< Malachi 3 >
1 “Wò ó, Èmi yóò ran ìránṣẹ́ mi, yóò tún ọ̀nà ṣe ṣáájú mi. Nígbà náà ni Olúwa, tí ẹ̀yin ń wa, yóò dé ni òjijì sí tẹmpili rẹ̀; àní oníṣẹ́ májẹ̀mú náà, tí inú yín dùn sí, yóò dé,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Voilà que J'envoie Mon ange, et il surveillera la voie devant Moi, et le Seigneur que vous cherchez viendra soudain dans Son temple, avec l'ange de l'alliance que vous avez désiré; Le voici, Il vient, dit le Seigneur tout- puissant.
2 Ṣùgbọ́n ta ni o lè fi ara da ọjọ́ dídé rẹ̀? Ta ni yóò sì dúró nígbà tí ó bá fi ara hàn? Nítorí òun yóò dàbí iná ẹni tí ń da fàdákà àti bi ọṣẹ alágbàfọ̀.
Et qui donc aura le pied ferme le jour de Sa venue? Qui supportera Sa présence? Il vient comme le feu d'une fournaise, ou comme l'herbe à foulons.
3 Òun yóò sì jókòó bí ẹni tí n yọ́, tí ó sì ń da fàdákà; yóò wẹ àwọn ọmọ Lefi mọ́, yóò sì tún wọn dàbí wúrà àti fàdákà, kí wọn bá a lè mú ọrẹ òdodo wá fún Olúwa,
Il siégera pour fondre et purifier, comme on purifie l'argent et l'or, et Il purifiera les fils de Lévi, et Il les coulera comme l'or et l'argent. Et ils offriront des victimes au Seigneur selon la justice.
4 nígbà náà ni ọrẹ Juda àti ti Jerusalẹmu yóò jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ti ọjọ́ àtijọ́, àti gẹ́gẹ́ bí ọdún ìgbàanì.
Et les sacrifices de Juda et de Jérusalem seront agréables au Seigneur, comme durant les jours anciens, comme durant les années d'autrefois.
5 “Èmi ó sì súnmọ́ yin fún ìdájọ́. Èmi yóò sì yára ṣe ẹlẹ́rìí sí àwọn oṣó, sí àwọn panṣágà, sí àwọn abúra èké, àti àwọn tí ó fi ọ̀yà alágbàṣe pọn wọn lójú, àti àwọn tí ó ni àwọn opó àti àwọn aláìní baba lára, àti sí ẹni tí kò jẹ́ kí àjèjì rí ìdájọ́ òdodo gbà, tí wọn kò sì bẹ̀rù mi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Et Je M'approcherai de vous en jugement, et Je serai un témoin empressé contre les magiciens, contre les femmes adultères, contre ceux qui prennent en vain Mon Nom, contre ceux qui retiennent le salaire du journalier, contre ceux qui oppriment la veuve, contre ceux qui maltraitent l'orphelin, contre ceux qui faussent le jugement envers l'étranger et n'ont pas la crainte de Moi, dit le Seigneur tout-puissant.
6 “Èmi Olúwa kò yípadà. Nítorí náà ni a kò ṣe run ẹ̀yin ọmọ Jakọbu.
Car Je suis le Seigneur votre Dieu, et Je ne change pas.
7 Láti ọjọ́ àwọn baba ńlá yín wá ni ẹ̀yin tilẹ̀ ti kọ ẹ̀yìn sí ìlànà mi, tí ẹ kò sì pa wọ́n mọ́. Ẹ padà wá sí ọ̀dọ̀ mi, Èmi yóò sì padà sí ọ̀dọ̀ yín,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, ‘Báwo ni àwa yóò ṣe padà?’
Et vous, fils de Jacob, vous ne vous êtes point abstenus des iniquités de vos pères; vous vous êtes retirés de Ma loi, et vous ne l'avez point gardée. Convertissez-vous à Moi, et Je reviendrai à vous, dit le Seigneur tout- puissant. Et vous avez dit: En quoi nous convertirons-nous?
8 “Ènìyàn yóò ha ja Ọlọ́run ni olè bí? Síbẹ̀ ẹ̀yin ti jà mí ní olè. “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, ‘Báwo ni àwa ṣe jà ọ́ ní olè?’ “Nípa ìdámẹ́wàá àti ọrẹ.
Est-ce que l'homme fera tomber Dieu dans ses pièges? Car vous cherchez à Me tromper; et vous direz: En quoi cherchons-nous à Te tromper? C'est en retenant pour vous les dîmes et les prémices.
9 Ríré ni a ó fi yín ré: gbogbo orílẹ̀-èdè yìí, nítorí ẹ̀yin ti jà mi lólè.
Vous M'avez regardé avec mépris, et vous avez cherché à Me tromper. L'année est révolue,
10 Ẹ mú gbogbo ìdámẹ́wàá wá sí ilé ìṣúra, kí oúnjẹ bá à lè wà ní ilé mi, ẹ fi èyí dán mi wò,” ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “kí ẹ sì wò bí èmi kò bá ní sí àwọn fèrèsé ọ̀run fún yin, kí èmi sì tú ìbùkún àkúnwọ́sílẹ̀ jáde fún yín, tó bẹ́ẹ̀ tí kì yóò sì ààyè láti gbà á.
et vous avez porté toutes les récoltes dans vos greniers; mais elles seront mises au pillage en chaque maison. Convertissez-vous sur ce point, dit le Seigneur tout-puissant. Et vous verrez alors si Je n'ouvrirai pas pour vous les cataractes du ciel, et si Je ne répandrai pas sur vous Ma bénédiction, jusqu'à ce que vous soyez satisfaits.
11 Èmi yóò sì bá kòkòrò ajẹnirun wí nítorí yín, òun kò sì ni run èso ilẹ̀ yín, bẹ́ẹ̀ ni àjàrà inú oko yín kò ní rẹ̀ dànù,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Et Je vous distribuerai votre nourriture, et Je n'endommagerai pas les fruits de votre champ, et votre vigne ne souffrira d'aucune maladie dans votre terre, dit le Seigneur tout-puissant.
12 “Nígbà náà ni gbogbo orílẹ̀-èdè yóò sì pè yín ni alábùkún fún, nítorí tiyín yóò jẹ́ ilẹ̀ tí ó wu ni,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Et toutes les nations vous estimeront heureux, parce que vous serez une terre bien-aimée, dit le Seigneur tout-puissant.
13 “Ẹ̀yin ti sọ ọ̀rọ̀ líle sí mi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Síbẹ̀ ẹ̀yin béèrè pé, ‘Ọ̀rọ̀ kín ni àwa sọ sí ọ?’
Vous avez tenu contre Moi des discours injurieux, dit le Seigneur, et vous avez dit: En quoi avons-nous parlé contre Toi?
14 “Ẹ̀yin ti wí pé, ‘Asán ni láti sin Ọlọ́run. Kí ni àwa jẹ ní èrè, nígbà tí àwa ti pa ìlànà rẹ mọ́, tí àwa sì ń rìn kiri bí ẹni tí ń ṣọ̀fọ̀ ní iwájú Olúwa àwọn ọmọ-ogun?
Et vous avez dit: Bien fou qui sert le Seigneur; qu'avons-nous de plus pour avoir gardé Ses commandements, et avoir paru comme suppliants devant Sa face?
15 Ṣùgbọ́n ní ìsinsin yìí àwa pé agbéraga ni alábùkún fún. Ní òtítọ́ ni àwọn ti ń ṣe búburú ń gbèrú sí i, kódà àwọn ti ó dán Ọlọ́run wò ni a dá sí.’”
Et maintenant nous estimons heureux les étrangers, ils se sont enrichis à mal faire; ils ont résisté à Dieu et ils ont été sauvés.
16 Nígbà náà ni àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa ń ba ara wọn sọ̀rọ̀, Olúwa sì tẹ́tí sí i, ó sì gbọ́. A sì kọ ìwé ìrántí kan níwájú rẹ̀, fún àwọn tí o bẹ̀rù Olúwa, tiwọn sì bọ̀wọ̀ fún orúkọ rẹ̀.
Mais bien autrement ont parlé les hommes craignant Dieu. Et le Seigneur a été attentif, et Il a écouté, et Il a écrit un livre, un mémorial devant Lui, pour ceux qui craignent le Seigneur et vénèrent Son Nom.
17 “Wọn yóò sì jẹ́ tèmi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “ni ọjọ́ náà, tí èmi ó dá; èmi yóò sì da wọ́n sí gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí máa ń dá ọmọ rẹ̀ tí yóò sìn ín sí.
Et ils seront à Moi, dit le Seigneur Dieu tout-puissant, le jour que Je ferai naître, pour Me les réserver, et Je les aimerai comme un homme aime son fils qui le sert.
18 Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò rí ìyàtọ̀, ìyàtọ̀ láàrín olódodo àti ẹni búburú, láàrín ẹni tí ń sìn Ọlọ́run, àti ẹni tí kò sìn ín.
Et vous vous convertirez, et vous distinguerez le juste du méchant; le serviteur de Dieu, de celui qui refuse de Le servir.