< Malachi 3 >
1 “Wò ó, Èmi yóò ran ìránṣẹ́ mi, yóò tún ọ̀nà ṣe ṣáájú mi. Nígbà náà ni Olúwa, tí ẹ̀yin ń wa, yóò dé ni òjijì sí tẹmpili rẹ̀; àní oníṣẹ́ májẹ̀mú náà, tí inú yín dùn sí, yóò dé,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
The Commander of the armies of angels says [this]: “Listen! I [am about to] send my messenger who will prepare [the people to receive me] when I come. [You claim that] [IRO] you are wanting to see me, and I will suddenly come to my temple. The messenger [who will tell you about a new] agreement, the one whom you are eagerly [SAR] awaiting, is certainly going to come [to you].”
2 Ṣùgbọ́n ta ni o lè fi ara da ọjọ́ dídé rẹ̀? Ta ni yóò sì dúró nígbà tí ó bá fi ara hàn? Nítorí òun yóò dàbí iná ẹni tí ń da fàdákà àti bi ọṣẹ alágbàfọ̀.
But will anyone [RHQ] be able to survive when he comes? Will anyone [RHQ] be able to [remain] standing in front of him? [Certainly not, ] because he will be like [SIM] a blazing fire that refines/purifies [metal/gold]. He will be like [SIM] a very strong soap [that bleaches clothes].
3 Òun yóò sì jókòó bí ẹni tí n yọ́, tí ó sì ń da fàdákà; yóò wẹ àwọn ọmọ Lefi mọ́, yóò sì tún wọn dàbí wúrà àti fàdákà, kí wọn bá a lè mú ọrẹ òdodo wá fún Olúwa,
[He will be like a worker who] sits [in front of his work] to cause silver to become pure by burning all the impurities. Like [a worker refines] silver and gold, he will cause the (descendants of Levi/priests) to become pure, [in order that they will again become acceptable to] offer sacrifices that will be acceptable to him.
4 nígbà náà ni ọrẹ Juda àti ti Jerusalẹmu yóò jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ti ọjọ́ àtijọ́, àti gẹ́gẹ́ bí ọdún ìgbàanì.
When that happens, Yahweh will [again] accept the offerings brought to him by [the people of] Jerusalem and [other places in] Judah, as [he did] previously.
5 “Èmi ó sì súnmọ́ yin fún ìdájọ́. Èmi yóò sì yára ṣe ẹlẹ́rìí sí àwọn oṣó, sí àwọn panṣágà, sí àwọn abúra èké, àti àwọn tí ó fi ọ̀yà alágbàṣe pọn wọn lójú, àti àwọn tí ó ni àwọn opó àti àwọn aláìní baba lára, àti sí ẹni tí kò jẹ́ kí àjèjì rí ìdájọ́ òdodo gbà, tí wọn kò sì bẹ̀rù mi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
[This is what] the Commander of the armies of angels says: “At that time, I will come to you to judge you. I will quickly testify against [all] those who practice sorcery/witchcraft, [all] who have committed adultery, and [all] liars. [I will testify] against those who have not given their workers the pay/wages that they promised, those who (oppress/treat cruelly) widows and orphans, and those who do not allow foreigners who live among you to be treated fairly. [I will testify that all] the people who do those things do not revere me.”
6 “Èmi Olúwa kò yípadà. Nítorí náà ni a kò ṣe run ẹ̀yin ọmọ Jakọbu.
“I am Yahweh, and I never change. And although you [deceive people like] your ancestor Jacob did, I have not [yet] gotten rid of you.
7 Láti ọjọ́ àwọn baba ńlá yín wá ni ẹ̀yin tilẹ̀ ti kọ ẹ̀yìn sí ìlànà mi, tí ẹ kò sì pa wọ́n mọ́. Ẹ padà wá sí ọ̀dọ̀ mi, Èmi yóò sì padà sí ọ̀dọ̀ yín,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, ‘Báwo ni àwa yóò ṣe padà?’
You and your ancestors have ignored my commands and you have not obeyed them. [Now] return to me; and when that happens, I will (return/do good) to you. [That is what I, ] the Commander of the armies of angels, say.” But you ask, “[We have never gone away from you, so] how can we return [to you]?”
8 “Ènìyàn yóò ha ja Ọlọ́run ni olè bí? Síbẹ̀ ẹ̀yin ti jà mí ní olè. “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, ‘Báwo ni àwa ṣe jà ọ́ ní olè?’ “Nípa ìdámẹ́wàá àti ọrẹ.
[I reply, ] “People should certainly not [RHQ] cheat God; but you people have cheated me!” You ask, “In what way did we cheat you?” [I reply, ] “[You have cheated me by not bringing to me each year] (the tithes/one tenth of [all] your crops and animals) and [other] offerings [that you are required to give to me].
9 Ríré ni a ó fi yín ré: gbogbo orílẹ̀-èdè yìí, nítorí ẹ̀yin ti jà mi lólè.
All that you do is cursed, because all you people in this country have been cheating me.
10 Ẹ mú gbogbo ìdámẹ́wàá wá sí ilé ìṣúra, kí oúnjẹ bá à lè wà ní ilé mi, ẹ fi èyí dán mi wò,” ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “kí ẹ sì wò bí èmi kò bá ní sí àwọn fèrèsé ọ̀run fún yin, kí èmi sì tú ìbùkún àkúnwọ́sílẹ̀ jáde fún yín, tó bẹ́ẹ̀ tí kì yóò sì ààyè láti gbà á.
[Now] bring all the tithes to the storage rooms [in the temple], in order that there will be [enough] food [for the people who serve me] there. If you do that, I, the Commander of the armies of angels, promise that I will open the windows of heaven, and pour out [from them] blessings on you. [If you bring your tithes to the temple, the blessings will be] very great, with the result that you will not have enough space to store all of them. So test me [to see if I am telling the truth].
11 Èmi yóò sì bá kòkòrò ajẹnirun wí nítorí yín, òun kò sì ni run èso ilẹ̀ yín, bẹ́ẹ̀ ni àjàrà inú oko yín kò ní rẹ̀ dànù,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
You will have abundant crops [to harvest], because I will protect them in order that they will not be harmed by locusts/insects. Your grapes will not fall from the vines [before they are ripe].
12 “Nígbà náà ni gbogbo orílẹ̀-èdè yóò sì pè yín ni alábùkún fún, nítorí tiyín yóò jẹ́ ilẹ̀ tí ó wu ni,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
When that happens, [the people of] all nations will say that [I] have blessed you, because your country will be delightful. [That is what I, ] the Commander of the armies of angels, say.
13 “Ẹ̀yin ti sọ ọ̀rọ̀ líle sí mi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Síbẹ̀ ẹ̀yin béèrè pé, ‘Ọ̀rọ̀ kín ni àwa sọ sí ọ?’
[I, ] Yahweh, [have something else] to say [to you]. You have said terrible things about me.” But you reply, “What terrible things have we said about you?”
14 “Ẹ̀yin ti wí pé, ‘Asán ni láti sin Ọlọ́run. Kí ni àwa jẹ ní èrè, nígbà tí àwa ti pa ìlànà rẹ mọ́, tí àwa sì ń rìn kiri bí ẹni tí ń ṣọ̀fọ̀ ní iwájú Olúwa àwọn ọmọ-ogun?
[I reply], “You have said, ‘It is useless [for us] to serve God. We have gained nothing [RHQ] by obeying the commands that he gave [to us] and by trying to show the Commander of the armies of angels that we are sorry [for the sins that we have committed].
15 Ṣùgbọ́n ní ìsinsin yìí àwa pé agbéraga ni alábùkún fún. Ní òtítọ́ ni àwọn ti ń ṣe búburú ń gbèrú sí i, kódà àwọn ti ó dán Ọlọ́run wò ni a dá sí.’”
From now on, we will say/consider that those who are proud are [the ones whom God has] blessed. [We will say that because it seems that it is] those who do evil who become rich, and [that it is] those who try to find out how many evil things they can do without God punishing them who are not punished.’”
16 Nígbà náà ni àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa ń ba ara wọn sọ̀rọ̀, Olúwa sì tẹ́tí sí i, ó sì gbọ́. A sì kọ ìwé ìrántí kan níwájú rẹ̀, fún àwọn tí o bẹ̀rù Olúwa, tiwọn sì bọ̀wọ̀ fún orúkọ rẹ̀.
After [the people heard my message], those who revered Yahweh discussed [those things] with each other, and Yahweh listened to what they said. While Yahweh was watching, they wrote on a scroll the things that would remind them [about what they promised], and they wrote on that scroll the names of those who revered Yahweh and who [said that they] always wanted to honor him [MTY].
17 “Wọn yóò sì jẹ́ tèmi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “ni ọjọ́ náà, tí èmi ó dá; èmi yóò sì da wọ́n sí gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí máa ń dá ọmọ rẹ̀ tí yóò sìn ín sí.
The Commander of the armies of angels says this [about those people]: “They will be my people. At the time that I judge people, [they will be like] [MET] a special treasure to me. I will be kind to them, like [SIM] fathers are kind to their sons who obey them.
18 Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò rí ìyàtọ̀, ìyàtọ̀ láàrín olódodo àti ẹni búburú, láàrín ẹni tí ń sìn Ọlọ́run, àti ẹni tí kò sìn ín.
When that happens, you will again see that [the manner in which I treat] righteous people is different from [the manner in which I treat] wicked people. [You will see that the manner in which I act toward] those who serve me is different from [the manner in which I act toward] those who do not.”