< Malachi 2 >

1 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ̀yin àlùfáà, òfin yìí ní fún yín.
Därför kommer nu följande bud till eder, I präster.
2 Bí ẹ̀yin kò bá ni gbọ́, bí ẹ̀yin kò bá ní fi í sí àyà láti fi ọ̀wọ̀ fún orúkọ mi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí; èmi yóò sì ran ègún sí orí yín, èmi yóò sì fi ìbùkún yín ré. Nítòótọ́ mó ti fi ré ná, nítorí pé, ẹ̀yin kò fi sí ọkàn yín láti bu ọlá fún mi.
Om I icke hörsammen det och akten därpå, så att I given mitt namn ära, säger HERREN Sebaot, så skall jag sända förbannelse över eder och förbanna edra välsignelser; ja, jag har redan förbannat dem, eftersom I icke akten därpå.
3 “Nítorí tiyín èmí yóò ba àwọn ọmọ yín wí, èmi ó sì fi ìgbẹ́ rẹ́ yín lójú, àní àwọn ìgbẹ́ ọrẹ ọwọ́ yín wọ̀nyí, a ó sì kó yín lọ pẹ̀lú rẹ̀.
Se, jag skall låta min näpst drabba eder avkomma, och jag skall kasta orenlighet i ansiktet på eder, orenligheten efter edra högtidsoffer; ja, I skolen själva bliva kastade i denna.
4 Ẹ̀yin ó sì mọ̀ pé, èmi ni ó ti rán òfin yìí sí yín, kí májẹ̀mú mi pẹ̀lú Lefi lè tẹ̀síwájú,” ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Då skolen I förstå, att jag har sänt till eder detta bud, för att mitt förbund med Levi skall bestå, säger HERREN Sebaot.
5 “Májẹ̀mú mi wà pẹ̀lú rẹ̀, májẹ̀mú ti ìyè àti àlàáfíà wà pẹ̀lú rẹ̀; mo sì fi wọn fún un, nítorí bíbẹ̀rù tí ó bẹ̀rù mi, tí ẹ̀rù orúkọ mi sì bà á.
Jag hade ett förbund med honom, och däri var liv och frid. Sådant gav jag åt honom, för att han skulle frukta mig; och han fruktade mig och bävade för mitt namn.
6 Òfin òtítọ́ wà ni ẹnu rẹ̀, a kò sì rí irọ́ ni ètè rẹ̀: ó ba mi rìn ní àlàáfíà àti ni ìdúró ṣinṣin, ó sì yí ọ̀pọ̀lọpọ̀ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀.
Rätt undervisning var i hans mun, och ingen orätt fanns på hans läppar; fridsamt och redligt vandrade han i min umgängelse och omvände många från missgärning.
7 “Nítorí ètè àlùfáà ní òye láti máa pa ìmọ̀ mọ́, kí àwọn ènìyàn lè máa wá ìtọ́ni ni ẹnu rẹ̀: nítorí òun ni ìránṣẹ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
Ty prästens läppar skola förvara kunskap, och undervisning skall man hämta ur hans mun; han är ju HERREN Sebaots sändebud.
8 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti yapa kúrò ní ọ̀nà náà; ẹ̀yin sì ti fi ìkọ́ni yín mú ọ̀pọ̀lọpọ̀ kọsẹ̀; ẹ̀yin ti ba májẹ̀mú tí mo da pẹ̀lú Lefi jẹ́,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Men I haven vikit av ifrån vägen; genom eder undervisning haven I kommit många på fall. I haven fördärvat förbundet med Levi, säger HERREN Sebaot.
9 “Nítorí náà ni èmi pẹ̀lú ṣe sọ yín di ẹ̀gàn, àti ẹni àìkàsí níwájú gbogbo ènìyàn, nítorí ẹ̀yin kò tẹ̀lé ọ̀nà mi, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ń ṣe ojúsàájú nínú òfin.”
Därför har ock jag gjort eder föraktade och låga i allt folkets ögon, eftersom I icke hållen mina vägar, utan haven anseende till personen, när I handhaven undervisningen.
10 Baba kan náà kí gbogbo wa ha ní? Ọlọ́run kan náà kọ́ ni ó dá wa bí? Nítorí kín ni àwa ha ṣe sọ májẹ̀mú àwọn baba wa di aláìmọ nípa híhu ìwà àrékérekè olúkúlùkù sí arákùnrin rẹ̀?
Hava vi icke alla en och samma fader? Har icke en och samma Gud skapat oss? Varför handla vi då trolöst mot varandra och bryta våra fäders förbund?
11 Juda ti ń hùwà àrékérekè, a sì ti hùwà ìríra ní Israẹli àti ni Jerusalẹmu: nítorí Juda tí sọ ìwà mímọ́ Olúwa di aláìmọ́, èyí tí ó fẹ́, nípa gbígbé ọmọbìnrin ọlọ́run àjèjì ni ìyàwó.
Juda har handlat trolöst, och styggelse är bedriven i Israel och i Jerusalem; ty Juda har oskärat HERRENS helgedom, den som han älskar, och de hava tagit till äkta kvinnor, som dyrka främmande gudar.
12 Ní ti ẹni tí ó ṣe èyí, ẹni tí ó wù kí ó jẹ, kí Olúwa kí ó gé e kúrò nínú àgọ́ Jakọbu, bí ó tilẹ̀ mú ẹbọ ọrẹ wá fún Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
Hos den man som så gör må HERREN utrota var levande själ ur Jakobs hyddor, jämväl den som frambär offergåvor till HERREN Sebaot.
13 Èyí ni ohun mìíràn tí ẹ̀yin sì túnṣe. Ẹ̀yin fi omijé bo pẹpẹ Olúwa mọ́lẹ̀. Ẹ̀yin sọkún, ẹ̀yin sì ba ara jẹ́ nítorí tì Òun kò ka ọrẹ yín sí mọ́, tàbí kí ó fi inú dídùn gba nǹkan yìí lọ́wọ́ yín.
Och ännu något annat gören I: I vållen, att HERRENS altare höljes med tårar, med gråt och klagan, så att han icke mer vill se till offergåvorna, ej heller med välbehag kan taga emot något ur eder hand.
14 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin wí pé, “Nítorí kín ní?” Nítorí Olúwa ti ṣe ẹlẹ́rìí láàrín ìwọ àti láàrín aya èwe rẹ, ẹni tí ìwọ ti ń hùwà ẹ̀tàn sí i: bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkejì rẹ ni òun jẹ́, àti aya májẹ̀mú rẹ.
Nu frågen I: "Huru så?" Jo, HERREN var ju vittne mellan dig och din ungdoms hustru, henne som du nu har varit trolös emot, fastän hon är din maka, din äkta hustru.
15 Ọlọ́run kò ha ti ṣe wọ́n ní ọ̀kan? Ni ara àti ni ẹ̀mí tirẹ̀ ni. Èéṣe tí Ọlọ́run da yín lọ́kàn? Kí òun bá à lè wá irú-ọmọ bí ti Ọlọ́run. Nítorí náà, ẹ tọ́jú ẹ̀mí yín, ẹ má sì ṣe hùwà ẹ̀tàn sí aya èwe yín.
Hava vi då icke en och samma skapare, den, i vilkens hand det står, att vår ande bevaras? Och vad vill nu denne ene? Han vill ju hava ett gudaktigt släkte. Tagen eder därför väl till vara, så att ingen bliver trolös mot sin ungdoms hustru.
16 “Ọkùnrin tí ó bá kórìíra, tí ó sì kọ ìyàwó rẹ̀,” se ìwà ipá sí ẹni tí ó yẹ kí ó dá ààbò bò, ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun. Nítorí náà, ẹ ṣọ́ ẹ̀mí yín, kí ẹ má ṣe hùwà ẹ̀tàn.
Ty jag hatar äktenskapsskillnad, säger HERREN, Israels Gud, och att man höljer sig i våld såsom i en överklädnad, säger HERREN Sebaot. Tagen eder därför väl till vara, så att I icke bliven trolösa.
17 Ẹ̀yin ti fi ọ̀rọ̀ yín dá Olúwa ní agara. Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, “Nínú kín ni àwa fi dá a ní agara?” Nígbà tí ẹ̀yìn wí pé, “Gbogbo ẹni tí ó ṣe ibi, rere ni níwájú Olúwa, inú rẹ̀ sì dùn sí wọn,” tàbí “Níbo ni Ọlọ́run ìdájọ́ gbé wà?”
I trötten ut HERREN med edert tal. Nu frågen I: "Varmed trötta vi då ut honom?" Jo, därmed att I sägen: "Den som gör ont är ändå god i HERRENS ögon, och till sådana har han behag. Ty varför kommer icke eljest domens Gud?"

< Malachi 2 >