< Malachi 1 >
1 Ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀: ọ̀rọ̀ Olúwa sí Israẹli láti ẹnu Malaki.
Brzemię słowa PANA do Izraela przez Malachiasza.
2 “Èmí ti fẹ́ ẹ yín,” ni Olúwa wí. “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, ‘Báwo ni ìwọ ṣe fẹ́ wa?’ “Esau kì í ha ṣe arákùnrin Jakọbu bí?” ni Olúwa wí. “Síbẹ̀ èmi fẹ́ràn Jakọbu,
Umiłowałem was, mówi PAN, a [wy] mówicie: W czym nas umiłowałeś? Czy Ezaw nie [był] bratem Jakuba? – mówi PAN, a jednak umiłowałem Jakuba;
3 ṣùgbọ́n Esau ni mo kórìíra, mo ti sọ àwọn òkè ńlá rẹ̀ di aṣálẹ̀, mo sì fi ìní rẹ̀ fún àwọn akátá aginjù.”
A Ezawa znienawidziłem i wydałem jego góry [na] spustoszenie, a jego dziedzictwo – smokom na pustkowiu.
4 Edomu lè wí pé, “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a run wá, àwa yóò padà wá, a ó sì tún ibùgbé náà kọ́.” Ṣùgbọ́n èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé: “Àwọn lè kọ́, ṣùgbọ́n èmi yóò wó palẹ̀. Wọn yóò sì pè wọ́n ní ilẹ̀ búburú, àwọn ènìyàn tí wọ́n máa ń wà ní ìbínú Olúwa.
Choćby Edom powiedział: Staliśmy się ubodzy, ale wrócimy i odbudujemy spustoszone [miejsca], to tak mówi PAN zastępów: Niech oni budują, a ja zburzę; i nazwą ich granicą bezbożności oraz ludem, na który PAN zapałał gniewem aż na wieki.
5 Ẹ̀yin yóò sì fi ojú yín rí i, ẹ̀yin yóò sì wí pé, ‘Títóbi ni Olúwa, títóbi rẹ̀ tayọ kọjá agbègbè Israẹli.’
Wasze oczy spojrzą i powiecie: PAN będzie uwielbiony w granicach Izraela.
6 “Ọmọ a máa bu ọ̀wọ̀ fún baba rẹ̀, ọmọ ọ̀dọ̀ a sì máa bu ọlá fún olúwa rẹ̀. Ǹjẹ́ bí èmí bá jẹ́ baba, ọlá tí ó tọ́ sí mi ha dà? Bí èmi bá sì jẹ́ olúwa, ẹ̀rù tí ó tọ́ sí mi dà?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Ẹ̀yin ni, ẹ̀yin àlùfáà, ni ẹ ń gan orúkọ mi. “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, ‘Báwo ni àwa ṣe gan orúkọ rẹ?’
Syn czci ojca, a sługa swego pana. Jeśli więc jestem ojcem, gdzie jest moja cześć? Jeśli jestem panem, gdzie [jest] bojaźń przede mną? – mówi PAN zastępów do was, kapłani, którzy lekceważycie moje imię. Wy jednak mówicie: W czym lekceważymy twoje imię?
7 “Ẹ̀yin gbé oúnjẹ àìmọ́ sí orí pẹpẹ mi. “Ẹ̀yin sì tún béèrè pé, ‘Báwo ni àwa ṣe ṣe àìmọ́ sí ọ?’ “Nípa sísọ pé tábìlì Olúwa di ẹ̀gàn.
Przynosicie na mój ołtarz pokarm nieczysty i mówicie: Czym cię zanieczyściliśmy? [Tym], że mówicie: Stołem PANA [można] wzgardzić.
8 Nígbà tí ẹ̀yin mú afọ́jú ẹran wá fún ìrúbọ, ṣé èyí kò ha burú bí? Nígbà tí ẹ̀yin fi amúnkùn ún àti aláìsàn ẹran rú ẹbọ, ṣé èyí kò ha burú gidigidi bí? Ẹ dán an wò, ẹ fi wọ́n rú ẹbọ sí àwọn baálẹ̀ yín! Ṣé inú rẹ̀ yóò dùn sí yín? Ṣé yóò gbà yín?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Gdy bowiem przyprowadzacie na ofiarę to, co jest ślepe, [czyż] nie jest [to] zła rzecz? I gdy przyprowadzacie kulawe i chore, [czy to] nie [jest] zła rzecz? Ofiaruj to twemu namiestnikowi, zobaczysz, czy będzie mu się podobać. Czy przyjmie twoją osobę? – mówi PAN zastępów.
9 “Ní ìsinsin yìí, ẹ bẹ Ọlọ́run kí ó ṣàánú fún wa. Ṣùgbọ́n pẹ̀lú irú àwọn ẹbọ wọ̀nyí láti ọwọ́ yín wá, ṣé yóò gbà yín?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Dlatego teraz, proszę, przebłagajcie Boga, aby się zlitował nad nami. To się dzieje z waszych rąk, czy więc przyjmie waszą osobę? – mówi PAN zastępów.
10 “Hó ò! Ẹnìkan ìbá jẹ́ wà láàrín yín ti yóò sé ìlẹ̀kùn tẹmpili, pé kí ẹ má ba à ṣe dá iná asán lórí pẹpẹ mi mọ́! Èmi kò ní inú dídùn sí i yín,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò gba ọrẹ kan lọ́wọ́ yín.
Kto spośród was za darmo zamknąłby drzwi albo zapaliłby ogień na moim ołtarzu? Nie mam w was upodobania, mówi PAN zastępów, i nie przyjmę ofiary z waszej ręki.
11 Orúkọ mi yóò tóbi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, láti ìlà-oòrùn títí ó sì fi dé ìwọ̀-oòrùn. Ní ibi gbogbo ni a ó ti mú tùràrí àti ọrẹ mímọ́ wá fún orúkọ mi, nítorí orúkọ mi tóbi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Od wschodu słońca bowiem aż do jego zachodu moje imię [będzie] wielkie wśród pogan; na każdym miejscu będą składane mojemu imieniu kadzidło i ofiara czysta. Moje imię bowiem będzie wielkie wśród narodów, mówi PAN zastępów.
12 “Nítorí ẹ̀yin ti sọ ọ́ di àìmọ́, nínú èyí tí ẹ wí pé, ‘Tábìlì Olúwa di àìmọ́ àti èso rẹ̀,’ àní oúnjẹ rẹ̀ ni ohun ẹ̀gàn.
Lecz wy bezcześcicie je, [gdy] mówicie: Stół PANA [jest] nieczysty; a to, co kładziecie na nim, jest wzgardzonym pokarmem.
13 Ẹ̀yin wí pẹ̀lú pé, ‘Wò ó, irú àjàgà kín ni èyí!’ Ẹ̀yin sì yínmú sí i,” ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Nígbà tí ẹ̀yin sì mú èyí tí ó fi ara pa, arọ àti ọlọkùnrùn ẹran tí ẹ sì fi rú ẹbọ, Èmi o ha gba èyí lọ́wọ́ yín?” ni Olúwa wí.
Mówicie też: [Jakiż to] wysiłek! I parskacie na to, co mówi PAN zastępów, i przynosicie to, co jest rozszarpane, kulawe i chore, takie ofiary przynosicie. Czy [mam] to przyjąć z waszej ręki? – mówi PAN.
14 “Ṣùgbọ́n ègún ni fún ẹlẹ́tàn náà, tí ó ni akọ nínú ọ̀wọ́ ẹran rẹ̀, tí ó sì ṣe ìlérí láti fi lélẹ̀ tí ó sì fi ẹran tó lábùkù rú ẹbọ sí Olúwa; nítorí ọba ńlá ni Èmi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “ẹ̀rù sì ni orúkọ mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
[Niech] będzie przeklęty oszust, który mając w swej trzodzie samca, ślubuje, a składa Panu w ofierze to, co jest ułomne. Jestem bowiem wielkim Królem, mówi PAN zastępów, a moje imię jest straszne między narodami.