< Malachi 1 >
1 Ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀: ọ̀rọ̀ Olúwa sí Israẹli láti ẹnu Malaki.
Parole du Seigneur sur Israël transmise à Son envoyé; déposez-la maintenant dans vos cœurs.
2 “Èmí ti fẹ́ ẹ yín,” ni Olúwa wí. “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, ‘Báwo ni ìwọ ṣe fẹ́ wa?’ “Esau kì í ha ṣe arákùnrin Jakọbu bí?” ni Olúwa wí. “Síbẹ̀ èmi fẹ́ràn Jakọbu,
Je vous ai aimés, dit le Seigneur, et vous avez dit: En quoi donc nous as- Tu aimés? Ésaü n'était-il pas le frère de Jacob? dit le Seigneur; n'ai-Je point aimé Jacob
3 ṣùgbọ́n Esau ni mo kórìíra, mo ti sọ àwọn òkè ńlá rẹ̀ di aṣálẹ̀, mo sì fi ìní rẹ̀ fún àwọn akátá aginjù.”
et pris en haine Ésaü? J'ai voulu que ses confins fussent dévastés, et que son héritage devînt comme les maisons du désert.
4 Edomu lè wí pé, “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a run wá, àwa yóò padà wá, a ó sì tún ibùgbé náà kọ́.” Ṣùgbọ́n èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé: “Àwọn lè kọ́, ṣùgbọ́n èmi yóò wó palẹ̀. Wọn yóò sì pè wọ́n ní ilẹ̀ búburú, àwọn ènìyàn tí wọ́n máa ń wà ní ìbínú Olúwa.
Or si l'on dit: L'Idumée est détruite, revenons et repeuplons le désert, voici ce que dit le Seigneur: Ils rebâtiront, et Je renverserai, et leur terre sera surnommée l'impiété, et ce sera un peuple à qui le Seigneur sera hostile pour jamais.
5 Ẹ̀yin yóò sì fi ojú yín rí i, ẹ̀yin yóò sì wí pé, ‘Títóbi ni Olúwa, títóbi rẹ̀ tayọ kọjá agbègbè Israẹli.’
Et vos yeux verront cela, et vous direz: Le Seigneur a montré Sa puissance au delà des limites d'Israël.
6 “Ọmọ a máa bu ọ̀wọ̀ fún baba rẹ̀, ọmọ ọ̀dọ̀ a sì máa bu ọlá fún olúwa rẹ̀. Ǹjẹ́ bí èmí bá jẹ́ baba, ọlá tí ó tọ́ sí mi ha dà? Bí èmi bá sì jẹ́ olúwa, ẹ̀rù tí ó tọ́ sí mi dà?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Ẹ̀yin ni, ẹ̀yin àlùfáà, ni ẹ ń gan orúkọ mi. “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, ‘Báwo ni àwa ṣe gan orúkọ rẹ?’
Le fils glorifie le père, et le serviteur son maître; et si Je suis père, où est Ma gloire? Et si Je suis maître, où est la crainte que J'inspire? dit le Seigneur tout-puissant. Et vous, prêtres, c'est vous qui méprisez Mon Nom, et qui dites: En quoi méprisons-nous Ton Nom?
7 “Ẹ̀yin gbé oúnjẹ àìmọ́ sí orí pẹpẹ mi. “Ẹ̀yin sì tún béèrè pé, ‘Báwo ni àwa ṣe ṣe àìmọ́ sí ọ?’ “Nípa sísọ pé tábìlì Olúwa di ẹ̀gàn.
C'est vous qui présentez à l'autel des aliments souillés, et qui dites: En quoi les avons-nous souillés? Vous les avez souillés en disant: La table du Seigneur est souillée; et ce qu'on y déposait Tu l'as méprisé.
8 Nígbà tí ẹ̀yin mú afọ́jú ẹran wá fún ìrúbọ, ṣé èyí kò ha burú bí? Nígbà tí ẹ̀yin fi amúnkùn ún àti aláìsàn ẹran rú ẹbọ, ṣé èyí kò ha burú gidigidi bí? Ẹ dán an wò, ẹ fi wọ́n rú ẹbọ sí àwọn baálẹ̀ yín! Ṣé inú rẹ̀ yóò dùn sí yín? Ṣé yóò gbà yín?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Si vous présentez pour le sacrifice une victime aveugle, n'est-ce point mal? Si vous en présentez une boiteuse ou malade, n'est-ce point mal? Offre-les à ton prince, et tu verras s'il te recevra, s'il accueillera ton visage, dit le Seigneur tout-puissant.
9 “Ní ìsinsin yìí, ẹ bẹ Ọlọ́run kí ó ṣàánú fún wa. Ṣùgbọ́n pẹ̀lú irú àwọn ẹbọ wọ̀nyí láti ọwọ́ yín wá, ṣé yóò gbà yín?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Maintenant priez devant votre Dieu, et adressez-Lui votre oraison; mais si de telles offrandes Me sont faites par vos mains, pourrai-Je bien accueillir vos visages? dit le Seigneur tout-puissant.
10 “Hó ò! Ẹnìkan ìbá jẹ́ wà láàrín yín ti yóò sé ìlẹ̀kùn tẹmpili, pé kí ẹ má ba à ṣe dá iná asán lórí pẹpẹ mi mọ́! Èmi kò ní inú dídùn sí i yín,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò gba ọrẹ kan lọ́wọ́ yín.
Et cependant chez vous les portes sont fermées, et vous n'allumez pas pour rien le feu de l'autel. Aussi Je ne Me complais pas en vous, dit le Seigneur tout-puissant, et Je n'accueillerai pas le sacrifice de vos mains.
11 Orúkọ mi yóò tóbi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, láti ìlà-oòrùn títí ó sì fi dé ìwọ̀-oòrùn. Ní ibi gbogbo ni a ó ti mú tùràrí àti ọrẹ mímọ́ wá fún orúkọ mi, nítorí orúkọ mi tóbi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Du lever du soleil à son coucher, Mon Nom a été glorifié parmi les gentils; en tout lieu on brûle en Mon Nom de l'encens et on offre une victime pure; parce que Mon Nom est grand parmi les nations, dit le Seigneur, Maître de toutes choses.
12 “Nítorí ẹ̀yin ti sọ ọ́ di àìmọ́, nínú èyí tí ẹ wí pé, ‘Tábìlì Olúwa di àìmọ́ àti èso rẹ̀,’ àní oúnjẹ rẹ̀ ni ohun ẹ̀gàn.
Et ce Nom vous Le profanez quand vous dites: La table du Seigneur est souillée, et les chairs que l'on y dépose sont méprisables.
13 Ẹ̀yin wí pẹ̀lú pé, ‘Wò ó, irú àjàgà kín ni èyí!’ Ẹ̀yin sì yínmú sí i,” ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Nígbà tí ẹ̀yin sì mú èyí tí ó fi ara pa, arọ àti ọlọkùnrùn ẹran tí ẹ sì fi rú ẹbọ, Èmi o ha gba èyí lọ́wọ́ yín?” ni Olúwa wí.
Vous avez dit encore: Ces offrandes sont le fruit de notre labeur; c'est pourquoi Je les ai rejetées avec mépris, dit le Seigneur tout-puissant; car vous Me présentez des victimes dérobées, ou boiteuses ou infirmes; et si vous Me les offrez en sacrifice, puis-Je les accepter de vos mains? dit le Seigneur tout-puissant.
14 “Ṣùgbọ́n ègún ni fún ẹlẹ́tàn náà, tí ó ni akọ nínú ọ̀wọ́ ẹran rẹ̀, tí ó sì ṣe ìlérí láti fi lélẹ̀ tí ó sì fi ẹran tó lábùkù rú ẹbọ sí Olúwa; nítorí ọba ńlá ni Èmi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “ẹ̀rù sì ni orúkọ mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
Maudit soit le riche qui possédait en son bétail un bélier voué au sacrifice, et qui sacrifie au Seigneur une chose corrompue; car Moi Je suis un grand roi, dit le Seigneur Dieu tout-puissant, et Mon Nom est éclatant parmi les nations.