< Luke 9 >

1 Ó sì pe àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ méjìlá jọ, ó sì fún wọn ní agbára àti àṣẹ lórí àwọn ẹ̀mí èṣù gbogbo, àti láti wo ààrùn sàn.
Men han sammenkaldte de tolv og gav dem Magt og Myndighed over alle de onde Aander og til at helbrede Sygdomme.
2 Ó sì rán wọn lọ wàásù ìjọba Ọlọ́run, àti láti mú àwọn ọlọkùnrùn láradá.
Og han sendte dem ud for at prædike Guds Rige og helbrede de syge.
3 Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ má ṣe mú nǹkan lọ́wọ́ fún àjò yín, ọ̀pá, tàbí àpò tàbí àkàrà, tàbí owó, bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ̀yin má sì ṣe ní ẹ̀wù méjì.
Og han sagde til dem: „Tager intet med paa Vejen, hverken Stav eller Taske eller Brød eller Penge, ej heller skal nogen have to Kjortler.
4 Ní ilékílé tí ẹ̀yin bá sì wọ̀, níbẹ̀ ni kí ẹ̀yin gbé, láti ibẹ̀ ni kí ẹ̀yin sì ti jáde.
Og hvor I komme ind i et Hus, der skulle I blive og derfra drage bort.
5 Iye àwọn tí kò bá si gbà yín, nígbà tí ẹ̀yin bá jáde kúrò ní ìlú náà, ẹ gbọn eruku ẹsẹ̀ yín fún ẹ̀rí sí wọn.”
Og hvor som helst de ikke modtage eder, fra den By skulle I gaa ud og endog ryste Støvet af eders Fødder til Vidnesbyrd imod dem.‟
6 Wọ́n sì lọ, wọ́n ń la ìletò kọjá wọ́n sì ń wàásù ìyìnrere, wọ́n sì ń mú ènìyàn láradá níbi gbogbo.
Men de gik ud og droge fra Landsby til Landsby, idet de forkyndte Evangeliet og helbredte alle Vegne.
7 Herodu tetrarki gbọ́ nǹkan gbogbo èyí tí a ṣe láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ wá: ó sì dààmú, nítorí tí àwọn ẹlòmíràn ń wí pé, Johanu ni ó jíǹde kúrò nínú òkú,
Men Fjerdingsfyrsten Herodes hørte alt det, som skete; og han var tvivlraadig, fordi nogle sagde, at Johannes var oprejst fra de døde;
8 Àwọn ẹlòmíràn sì wí pé Elijah ni ó farahàn; àwọn ẹlòmíràn sì wí pé, ọ̀kan nínú àwọn wòlíì àtijọ́ ni ó jíǹde.
men nogle, at Elias havde vist sig; men andre, at en af de gamle Profeter var opstanden.
9 Herodu sì wí pé, “Johanu ni mo ti bẹ́ lórí, ṣùgbọ́n ta ni èyí tí èmi ń gbọ́ irú nǹkan wọ̀nyí sí?” Ó sì ń fẹ́ láti rí i.
Men Herodes sagde: „Johannes har jeg ladet halshugge; men hvem er denne, om hvem jeg hører saadanne Ting?‟ Og han søgte at faa ham at se.
10 Nígbà tí àwọn aposteli sì padà dé, wọ́n ròyìn ohun gbogbo fún un tí wọ́n ti ṣe. Ó sì mú wọn, lọ sí apá kan níbi tí a ń pè ní Betisaida.
Og Apostlene kom tilbage og fortalte ham, hvor store Ting de havde gjort. Og han tog dem med sig og drog bort afsides til en By, som kaldes Bethsajda.
11 Nígbà tí ọ̀pọ̀ ènìyàn sì mọ̀, wọ́n tẹ̀lé e: ó sì gbà wọ́n, ó sì sọ̀rọ̀ ìjọba Ọlọ́run fún wọn; àwọn tí ó fẹ́ ìmúláradá, ni ó sì mú láradá.
Men da Skarerne fik det at vide, fulgte de efter ham; og han tog imod dem og talte til dem om Guds Rige og helbredte dem, som trængte til Lægedom.
12 Nígbà tí ọjọ́ bẹ̀rẹ̀ sí rọlẹ̀, àwọn méjìlá wá, wọ́n sì wí fún un pé, “Tú ìjọ ènìyàn ká, kí wọn lè lọ sí ìletò àti sí ìlú yíká, kí wọn lè wò, àti kí wọn lè wá oúnjẹ: nítorí ijù ni àwa sá wà níhìn-ín.”
Men Dagen begyndte at hælde. Og de tolv kom hen og sagde til ham: „Lad Skaren gaa bort, for at de kunne gaa herfra til de omliggende Landsbyer og Gaarde og faa Herberge og finde Føde; thi her ere vi paa et øde Sted.‟
13 Ṣùgbọ́n ó wí fún wọn pé, “Ẹ fi oúnjẹ fún wọn jẹ!” Wọ́n sì wí fún un pé, “Àwa kò ní ju ìṣù àkàrà márùn-ún lọ, pẹ̀lú ẹja méjì: bí kò ṣe pé àwa lọ ra oúnjẹ fún gbogbo àwọn ènìyàn wọ̀nyí.”
Men han sagde til dem: „Giver I dem at spise!‟ Men de sagde: „Vi have ikke mere end fem Brød og to Fisk, med mindre vi skulle gaa bort og købe Mad til hele denne Mængde.‟
14 Nítorí àwọn ọkùnrin náà tó ìwọ̀n ẹgbẹ̀rún márùn-ún ènìyàn. Ó sì wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Kí wọ́n mú wọn jókòó lẹ́gbẹ̀ẹ̀gbẹ́, ní àràádọ́ta.”
De vare nemlig omtrent fem Tusinde Mænd. Men han sagde til sine Disciple: „Lader dem sætte sig ned i Hobe, halvtredsindstyve i hver.‟
15 Wọ́n sì ṣe bẹ́ẹ̀, wọ́n sì mú gbogbo wọn jókòó.
Og de gjorde saa og lode dem alle sætte sig ned.
16 Nígbà náà ni ó mú ìṣù àkàrà márùn-ún, àti ẹja méjì náà, nígbà tí ó gbé ojú sókè ọ̀run, ó súre sí i, ó sì bù ú, ó sì fi fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, kí wọn gbé e kalẹ̀ níwájú àwọn ènìyàn.
Men han tog de fem Brød og de to Fisk, saa op til Himmelen og velsignede dem, og han brød dem og gav sine Disciple dem at lægge dem for Skaren.
17 Wọ́n sì jẹ, gbogbo wọn sì yó: wọ́n ṣa agbọ̀n méjìlá jọ nínú àjẹkù tí ó kù.
Og de spiste og bleve alle mætte; og det, som de fik tilovers af Stykker, blev opsamlet, tolv Kurve.
18 Ó sì ṣe, nígbà tí ó ku òun nìkan ó gbàdúrà, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sì wà lọ́dọ̀ rẹ̀: ó sì bi wọ́n pé, “Ta ni àwọn ènìyàn ń fi mí pè?”
Og det skete, medens han bad, vare hans Disciple alene hos ham; og han spurgte dem og sagde: „Hvem sige Skarerne, at jeg er?‟
19 Wọ́n sì dáhùn wí pé, “Johanu Onítẹ̀bọmi; ṣùgbọ́n ẹlòmíràn ní Elijah ni, àti àwọn ẹlòmíràn wí pé, ọ̀kan nínú àwọn wòlíì àtijọ́ ni ó jíǹde.”
Men de svarede og sagde: „Johannes Døberen; men andre: Elias; men andre: En af de gamle Profeter er opstanden.‟
20 Ó sì bi wọ́n pé, “Ṣùgbọ́n ta ni ẹ̀yin ń fi èmi pè?” Peteru sì dáhùn, wí pe, “Kristi ti Ọlọ́run.”
Og han sagde til dem: „Men I, hvem sige I, at jeg er?‟ Og Peter svarede og sagde: „Guds Kristus.‟
21 Ó sì kìlọ̀ fún wọn, pé, kí wọn má ṣe sọ èyí fún ẹnìkan.
Men han bød dem strengt ikke at sige dette til nogen,
22 Ó sì wí pé, “Ọmọ ènìyàn yóò jìyà ohun púpọ̀, a ó sì kọ̀ ọ́ láti ọ̀dọ̀ àwọn alàgbà, olórí àlùfáà àti láti ọ̀dọ̀ àwọn akọ̀wé, a ó sì pa á, ní ọjọ́ kẹta a ó sì jí i dìde.”
idet han sagde: „Menneskesønnen skal lide meget og forkastes af de Ældste og Ypperstepræsterne og de skriftkloge og ihjelslaas og oprejses paa den tredje Dag.‟
23 Ó sì wí fún gbogbo wọn pé, “Bí ẹnìkan bá ń fẹ́ láti máa tọ̀ mí lẹ́yìn, kí ó sẹ́ ara rẹ̀, kí ó sì gbé àgbélébùú rẹ̀ ní ọjọ́ gbogbo, kí ó sì máa tọ̀ mí lẹ́yìn.
Men han sagde til alle: „Vil nogen komme efter mig, han fornægte sig selv og tage sit Kors op daglig og følge mig;
24 Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá fẹ́ gba ọkàn rẹ̀ là, yóò sọ ọ́ nù: ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó bá sọ ọkàn rẹ̀ nù nítorí mi, òun náà ni yóò sì gbà á là.
thi den, som vil frelse sit Liv, skal miste det; men den, som mister sit Liv for min Skyld, han skal frelse det.
25 Nítorí pé èrè kín ni fún ènìyàn, bí ó jèrè gbogbo ayé, tí ó sì sọ ara rẹ̀ nù tàbí kí ó fi ṣòfò.
Thi hvad gavner det et Menneske, om han har vundet den hele Verden, men mistet sig selv eller bødet med sig selv?
26 Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá tijú mi, àti ọ̀rọ̀ mi, òun ni Ọmọ Ènìyàn yóò tijú rẹ̀ nígbà tí ó bá dé inú ògo tirẹ̀, àti ti baba rẹ̀, àti ti àwọn angẹli mímọ́.
Thi den, som skammer sig ved mig og mine Ord, ved ham skal Menneskesønnen skamme sig, naar han kommer i sin og Faderens og de hellige Engles Herlighed.
27 “Ṣùgbọ́n èmi wí fún yín nítòótọ́, ẹlòmíràn dúró níhìn-ín yìí, tí kì yóò rí ikú, títí wọn ó fi rí ìjọba Ọlọ́run.”
Men sandelig, siger jeg eder: Der er nogle af dem, som staa her, der ingenlunde skulle smage Døden, førend de se Guds Rige.‟
28 Ó sì ṣe bí ìwọ̀n ọjọ́ mẹ́jọ lẹ́yìn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, ó mú Peteru àti Johanu àti Jakọbu, ó gun orí òkè lọ láti lọ gbàdúrà.
Men det skete omtrent otte Dage efter denne Tale, at han tog Peter og Johannes og Jakob med sig og gik op paa Bjerget for at bede.
29 Bí ó sì ti ń gbàdúrà, àwọ̀ ojú rẹ̀ yípadà, aṣọ rẹ̀ sì funfun gbòò,
Og det skete, medens han bad, da blev hans Ansigts Udseende anderledes, og hans Klædebon blev hvidt og straalende.
30 Sì kíyèsi i, àwọn ọkùnrin méjì, Mose àti Elijah, wọ́n ń bá a sọ̀rọ̀,
Og se, to Mænd talte med ham, og det var Moses og Elias,
31 tí wọ́n fi ara hàn nínú ògo, wọ́n sì ń sọ̀rọ̀ ikú rẹ̀, tí òun yóò ṣe parí ní Jerusalẹmu.
som bleve sete i Herlighed og talte om hans Udgang, som han skulde fuldbyrde i Jerusalem.
32 Ṣùgbọ́n ojú Peteru àti ti àwọn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ wúwo fún oorun. Nígbà tí wọ́n sì tají, wọ́n rí ògo rẹ̀, àti ti àwọn ọkùnrin méjèèjì tí ó bá a dúró.
Men Peter og de, som vare med ham, vare betyngede af Søvn; men da de vaagnede op, saa de hans Herlighed og de to Mænd, som stode hos ham.
33 Ó sì ṣe, nígbà tí wọ́n lọ kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀, Peteru wí fún Jesu pé, “Olùkọ́, ó dára fún wa kí a máa gbé ìhín yìí, jẹ́ kí àwa pa àgọ́ mẹ́ta, ọ̀kan fún ìwọ, àti ọ̀kan fún Mose, àti ọ̀kan fún Elijah.” (Kò mọ èyí tí òun ń wí.)
Og det skete, da disse skiltes fra ham, sagde Peter til Jesus: „Mester! det er godt, at vi ere her; og lader os gøre tre Hytter, en til dig og en til Moses og en til Elias; ‟ men han vidste ikke, hvad han sagde.
34 Bí ó ti ń sọ báyìí, ìkùùkuu kan wá, ó síji bò wọ́n: ẹ̀rù sì bà wọ́n nígbà tí wọ́n ń wọ inú ìkùùkuu lọ.
Men idet han sagde dette, kom en Sky og overskyggede dem; men de frygtede, da de kom ind i Skyen.
35 Ohùn kan sì ti inú ìkùùkuu wá wí pé, “Èyí yìí ni àyànfẹ́ ọmọ mi: ẹ máa gbọ́ tirẹ̀.”
Og der kom fra Skyen en Røst, som sagde: „Denne er min Søn, den udvalgte, hører ham!‟
36 Nígbà tí ohùn náà sì dákẹ́, Jesu nìkan ṣoṣo ni a rí. Wọ́n sì pa á mọ́, wọn kò sì sọ ohunkóhun tí wọ́n rí fún ẹnikẹ́ni ní ọjọ́ wọ̀nyí.
Og da Røsten kom, blev Jesus funden alene. Og de tav og forkyndte i de Dage ingen noget af det, de havde set.
37 Ó sì ṣe, ní ọjọ́ kejì, nígbà tí wọ́n sọ̀kalẹ̀ wá láti orí òkè, ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn wá pàdé rẹ̀.
Men det skete Dagen derefter, da de kom ned fra Bjerget, at der mødte ham en stor Skare.
38 Sì kíyèsi i, ọkùnrin kan nínú ìjọ ènìyàn kígbe sókè pé, “Olùkọ́ mo bẹ̀ ọ́, wo ọmọ mi: nítorí ọmọ mi kan ṣoṣo náà ni.
Og se, en Mand af Skaren raabte og sagde: „Mester! jeg beder dig, se til min Søn; thi han er min enbaarne.
39 Sì kíyèsi i, ẹ̀mí èṣù a máa mú un, a sì máa kígbe lójijì; a sì máa nà án tàntàn títí yóò fi yọ ìfófó lẹ́nu, a máa pa á lára, kì í tilẹ̀ ń fẹ́ fi í sílẹ̀ lọ.
Og se, en Aand griber ham, og pludseligt skriger han, og den slider i ham, saa at han fraader, og med Nød viger den fra ham, idet den mishandler ham;
40 Mo sì bẹ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ láti lé e jáde: wọn kò sì lè ṣe é.”
og jeg bad dine Disciple om at uddrive den; og de kunde ikke.‟
41 Jesu sì dáhùn pé, “Ìran aláìgbàgbọ́ àti àrékérekè, èmi ó ti bá yín gbé pẹ́ tó? Èmi yóò sì ti ṣe sùúrù fún yín pẹ́ tó? Fa ọmọ rẹ wá níhìn-ín yìí.”
Men Jesus svarede og sagde: „O du vantro og forvendte Slægt! hvor længe skal jeg være hos eder og taale eder? Bring din Søn hid!‟
42 Bí ó sì ti ń bọ̀, ẹ̀mí èṣù náà gbé e ṣánlẹ̀, ó sì nà án tàntàn. Jesu sì bá ẹ̀mí àìmọ́ náà wí, ó sì mú ọmọ náà láradá, ó sì fà á lé baba rẹ̀ lọ́wọ́.
Men endnu medens han gik derhen, rev og sled den onde Aand i ham. Men Jesus truede den urene Aand og helbredte Drengen og gav hans Fader ham tilbage.
43 Ẹnu sì ya gbogbo wọn sí iṣẹ́ títóbi Ọlọ́run, ṣùgbọ́n nígbà tí hà sì ń ṣe gbogbo wọn sí ohun gbogbo tí Jesu ṣe, ó wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé,
Men de bleve alle slagne af Forundring over Guds Majestæt. Men da alle undrede sig over alt det, han gjorde, sagde han til sine Disciple:
44 “Ẹ jẹ́ kí ọ̀rọ̀ wọ̀nyí wọ̀ yín létí, nítorí a ó fi Ọmọ Ènìyàn lé àwọn ènìyàn lọ́wọ́.”
„Gemmer i eders Øren disse Ord: Menneskesønnen skal overgives i Menneskers Hænder.‟
45 Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ náà kò yé wọn, ó sì ṣú wọn lójú, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì mọ̀ ọ́n: ẹ̀rù sì ń bà wọ́n láti béèrè ìdí ọ̀rọ̀ náà.
Men de forstode ikke dette Ord, og det var skjult for dem, saa de ikke begrebe det, og de frygtede for at spørge ham om dette Ord.
46 Iyàn kan sì dìde láàrín wọn, ní ti ẹni tí yóò ṣe olórí nínú wọn.
Men der opstod den Tanke hos dem, hvem der vel var den største af dem.
47 Nígbà tí Jesu sì mọ èrò ọkàn wọn, ó mú ọmọdé kan, ó gbé e jókòó lọ́dọ̀ rẹ̀.
Men da Jesus saa deres Hjertes Tanke, tog han et Barn og stillede det hos sig.
48 Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá gba ọmọdé yìí nítorí orúkọ mi, ó gbà mí: àti ẹnikẹ́ni tí ó bá gbà mí, ó gba ẹni tí ó rán mi: nítorí ẹni tí ó bá kéré jù nínú gbogbo yín, òun náà ni yóò pọ̀jù.”
Og han sagde til dem: „Den, som modtager dette Barn for mit Navns Skyld, modtager mig; og den, som modtager mig, modtager den, som udsendte mig; thi den, som er den mindste iblandt eder alle, han er stor.‟
49 Johanu sì dáhùn ó sì wí fún un pé, “Olùkọ́, àwa rí ẹnìkan ó ń fi orúkọ rẹ lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde; àwa sì dá a lẹ́kun, nítorí tí kò bá wa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.”
Men Johannes tog til Orde og sagde: „Mester! vi saa en uddrive onde Aander i dit Navn; og vi forbøde ham det, fordi han ikke følger med os.‟
50 Jesu sì wí fún un, pé, “Má ṣe dá a lẹ́kun mọ́: nítorí ẹni tí kò bá lòdì sí i yín, ó wà fún yín.”
Men Jesus sagde til ham: „Forbyder ham det ikke; thi den, som ikke er imod eder, er for eder.‟
51 Nígbà tí ọjọ́ àti gbà á sókè ń súnmọ́, ó pinnu láti lọ sí Jerusalẹmu.
Men det skete, da hans Optagelses Dage vare ved at fuldkommes, da fæstede han sit Ansigt paa at drage til Jerusalem.
52 Ó sì rán àwọn ìránṣẹ́ lọ sí iwájú rẹ̀. Nígbà tí wọ́n sì lọ wọ́n wọ ìletò kan tí í ṣe ti ará Samaria láti pèsè sílẹ̀ dè é.
Og han sendte Sendebud forud for sig; og de gik og kom ind i en Samaritanerlandsby for at berede ham Herberge.
53 Wọn kò sì gbà á, nítorí pé ó ń lọ sí Jerusalẹmu.
Og de modtoge ham ikke, fordi han var paa Vejen til Jerusalem.
54 Nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ Jakọbu àti Johanu sì rí i, wọ́n ní, “Olúwa wa, jẹ́ kí a pe iná láti ọ̀run wá, kí a sì pa wọ́n run, bí Elijah ti ṣe?”
Men da hans Disciple, Jakob og Johannes, saa det, sagde de: „Herre! vil du, at vi skulle byde Ild fare ned fra Himmelen og fortære dem, ligesom ogsaa Elias gjorde?‟
55 Ṣùgbọ́n Jesu yípadà, ó sì bá wọn wí.
Men han vendte sig og irettesatte dem.
56 Lẹ́yìn náà Jesu àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sì lọ sí ìletò mìíràn.
Og de gik til en anden Landsby.
57 Bí wọ́n ti ń lọ lọ́nà, ọkùnrin kan wí fún un pé, “Olúwa, Èmi ń fẹ́ láti máa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn ní ibikíbi tí ìwọ bá ń lọ.”
Og medens de vandrede paa Vejen, sagde en til ham: „Jeg vil følge dig, hvor du end gaar hen.‟
58 Jesu sì wí fún un pé, “Àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ ní ihò, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run sì ní ìtẹ́; ṣùgbọ́n Ọmọ Ènìyàn kò ní ibi tí yóò fi orí rẹ̀ lé.”
Og Jesus sagde til ham: „Ræve have Huler, og Himmelens Fugle Reder; men Menneskesønnen har ikke det, hvortil han kan hælde sit Hoved.‟
59 Ó sì wí fún ẹlòmíràn pé, “Máa tọ̀ mí lẹ́yìn.” Ṣùgbọ́n èyí wí fún un pé, “Olúwa, jẹ́ kí èmi lọ sìnkú baba mi ná.”
Men han sagde til en anden: „Følg mig!‟ Men denne sagde: „Herre! tilsted mig først at gaa hen at begrave min Fader.‟
60 Jesu sì wí fún un pé, “Jẹ́ kí àwọn òkú máa sìnkú ara wọn, ṣùgbọ́n ìwọ lọ kí o sì máa wàásù ìjọba Ọlọ́run.”
Men han sagde til ham: „Lad de døde begrave deres døde; men gaa du hen og forkynd Guds Rige!‟
61 Ẹlòmíràn sì wí fún un pé, “Olúwa, èmi yóò tọ̀ ọ́ lẹ́yìn ṣùgbọ́n jẹ́ kí n kọ́kọ́ lọ dágbére fún àwọn ará ilé mi.”
Men ogsaa en anden sagde: „Herre! jeg vil følge dig; men tilsted mig først at tage Afsked med dem, som ere i mit Hus.‟
62 Jesu sì wí fún un pé, “Kò sí ẹni, tí ó fi ọwọ́ rẹ̀ lé ohun èlò ìtulẹ̀, tí ó sì wo ẹ̀yìn, tí ó yẹ fún ìjọba Ọlọ́run.”
Men Jesus sagde til ham: „Ingen, som lægger sin Haand paa Ploven og ser tilbage, er vel skikket for Guds Rige.‟

< Luke 9 >