< Luke 7 >

1 Nígbà tí ó sì parí gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ̀ fun àwọn ènìyàn, ó wọ Kapernaumu lọ.
Jesu n den maadi ya niba n maadi opo ya maama n tie na kuli ki gbeni, o den kua Kapenayuma dogu nni.
2 Ọmọ ọ̀dọ̀ balógun ọ̀rún kan, tí ó ṣọ̀wọ́n fún un, ṣàìsàn, ó sì ń kú lọ.
Mintela kobiga yudaano yendo den ye ki pia o naacemo ke o tie opo numoano, ke o yia ŋali ki bua ki kpe.
3 Nígbà tí ó sì gbúròó Jesu, ó rán àwọn àgbàgbà Júù sí i, ó ń bẹ̀ ẹ́ pé kí ó wá mú ọmọ ọ̀dọ̀ òun láradá.
O yudaano yeni n den gbadi ke bi maadi Jesu maama, o den soani Jufinba nukpeliba bi tianba o kani ke ban mia o wan cua ki faabi o naacemo.
4 Nígbà tí wọ́n sì dé ọ̀dọ̀ Jesu, wọ́n fi ìtara bẹ̀ ẹ́, pé, “Ó yẹ ní ẹni tí òun ìbá ṣe èyí fún.
Bi den pundi Jesu kani ki mia o ki moandi wan da yie ki yedi: “O joa yeni pundi ŋan ŋanbi opo,
5 Nítorí tí ó fẹ́ràn orílẹ̀-èdè wa, ó sì ti kọ́ Sinagọgu kan fún wa.”
kelima o bua ti buolu. Wani n maa tipo li balimaama bangima dieli.”
6 Jesu sì ń bá wọn lọ. Nígbà tí kò sì jìn sí etí ilé mọ́, balógun ọ̀rún náà rán àwọn ọ̀rẹ́ sí i, pé, “Olúwa, má ṣe yọ ara rẹ lẹ́nu, nítorí tí èmi kò yẹ tí ìwọ ìbá fi wọ abẹ́ òrùlé mi.
Jesu den yegi leni ba ki caa. Wan den kuli a minteela yudaano diegu, o den tuogi wan den soani o danlinba yaaba o kani ke ban yedi o: “N daano, da coagi a yuli, mii pundi ŋan kua n dieli nni.
7 Nítorí náà èmi kò sì rò pé èmi náà yẹ láti tọ̀ ọ́ wá, ṣùgbọ́n sọ ní gbólóhùn kan, a ó sì mú ọmọ ọ̀dọ̀ mi láradá.
Lanyaapo moko n teni ke mii sua ke li pundi min cua a kani mini nba. Maadi a maama bebe, n naacemo baa paagi.
8 Nítorí èmi náà pẹ̀lú jẹ́ ẹni tí a fi sí abẹ́ àṣẹ, tí ó ní ọmọ-ogun lẹ́yìn mi, mo sì wí fún ọ̀kan pé, ‘Lọ,’ a sì lọ; àti fún òmíràn pé, ‘Wá,’ a sì wá; àti fún ọmọ ọ̀dọ̀ mi pé, ‘Ṣe èyí,’ a sì ṣe é.”
Mini yua ke nitoaba die nni, n moko pia min die ya minteela. n yen yedi one: 'Gedi,' wan gedi, ki yedi o yua mo: 'Cua na,' wan cua. N yen yedi n naacemo: 'Tieni line,' wan tieni.”
9 Nígbà tí Jesu gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, ẹnu sì yà, ó sì yípadà sí ìjọ ènìyàn tí ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, ó wí pé, “Mo wí fún yín pé èmi kò rí irú ìgbàgbọ́ ńlá bí èyí nínú àwọn ènìyàn Israẹli.”
Jesu n den gbadi laa maama, li den tie opo bonlidinkaala, de ki mangi o. O den jigidi ki yedi ya niligu n ŋua o: “N waani yi ke baa Isalele yaaba siiga, n daa laa ya dandancianli n yene buolu.”
10 Nígbà tí àwọn oníṣẹ́ sì padà sí ilé, wọ́n bá ọmọ ọ̀dọ̀ náà tí ń ṣàìsàn, ara rẹ̀ ti dá.
Wan den soani yaaba n den lebidi ki pundi denpo, bi den sua ke ya naacemo n bi yia yeni pia laafia.
11 Ní ọjọ́ kejì, ó lọ sí ìlú kan tí a ń pè ní Naini, àwọn púpọ̀ nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sì ń bá a lọ àti ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn.
Lani n pendi Jesu den gedi Nayina dogu. O ŋoadikaaba leni nigocianli den yegi leni o.
12 Bí ó sì ti súnmọ́ ẹnu ibodè ìlú náà, sì kíyèsi i, wọ́n ń gbé òkú ọkùnrin kan jáde, ọmọ kan ṣoṣo náà tí ìyá rẹ̀ bí, ó sì jẹ́ opó: ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn ìlú náà sì wà pẹ̀lú rẹ̀.
Jesu n den nagini u dogu bilinciamu buliñoajabu, o den tuogi yaaba n ñani lienni ki tugi o kpiemo ki baan piini. Yua n kpe yeni den tie o naa tugu nni bonjayenyenga, ke o naa mo tie kpepuoli. U dogu yaaba boncianla den yegi leni o.
13 Nígbà tí Olúwa sì rí i, àánú rẹ̀ ṣe é, ó sì wí fún un pé, “Má sọkún mọ́.”
O Diedo n den laa o, mi niŋima den cuo o opo ke o yedi: “Da buudi.”
14 Ó sì wá, ó sì fi ọwọ́ tọ́ pósí náà: àwọn tí ń rù ú dúró jẹ́. Ó sì wí pé, “Ọ̀dọ́mọkùnrin, mo wí fún ọ, dìde!”
O den nagini ki sii ku tinkpikpagu. Yaaba n tugi den sedi. O den yedi: “O jawaalo na, n yedi a: 'Fii.'”
15 Ẹni tí ó kú náà sì dìde jókòó, ó bẹ̀rẹ̀ sí i fọhùn. Ó sì fà á lé ìyá rẹ̀ lọ́wọ́.
Lani yua kpe yeni den fii ki kali ki maadi. Jesu den teni o o naa.
16 Ẹ̀rù sì ba gbogbo wọn: wọ́n sì yin Ọlọ́run lógo, pé, “Wòlíì ńlá dìde nínú wa,” àti pé, “Ọlọ́run sì wá bẹ àwọn ènìyàn rẹ̀ wò!”
Li fangicianli den cuo laa niba kuli, bi den kpiagidi U Tienu ki tua: “O sawalipuaciamo fii ti siiga. U Tienu goandi o nibuolu.”
17 Òkìkí rẹ̀ sì kàn ní gbogbo Judea, àti gbogbo agbègbè tí ó yí i ká.
Jesu n den tieni yaala yeni kuli ya maama den yadi Jude nni leni ya tinmu n lindi kuli.
18 Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Johanu sì sọ gbogbo nǹkan wọ̀nyí fún un.
Jan ŋoadikaaba den togidi o laa bonla kuli.
19 Nígbà tí Johanu sì pe àwọn méjì nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, ó rán wọn sọ́dọ̀ Olúwa, wí pé, “Ìwọ ni ẹni tí ń bọ̀, tàbí kí a máa retí ẹlòmíràn?”
O den yini bi siiga ŋoadikaaba lie ki soani ba Jesu kani, ke ban yedi o: “Naani a tie yua n den baa cua bi, bi ti da go baa guudi nitoa yo?”
20 Nígbà tí àwọn ọkùnrin náà sì dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, wọ́n wí pé, “Johanu onítẹ̀bọmi rán wa sọ́dọ̀ rẹ, pé, ‘Ìwọ ni ẹni tí ń bọ̀, tàbí kí a máa retí ẹlòmíràn?’”
Bi jaba yeni n den pundi Jesu kani bi den yedi o: “Jan Batisi n soani ti a kani ke tin buali a fini n ya tie tin gu yua ya cuama bi, bi ke ti da go ya baa daani nitoa yo?”
21 Ní wákàtí náà, ó sì ṣe ìmúláradá ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn nínú àìsàn, àti ààrùn, àti ẹ̀mí búburú; ó sì fi ìríran fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn afọ́jú.
Lanyogunu Jesu den paagi a yiama leni a tadima leni mu cicibiadimu n die yaaba kuli boncianla, ki go noadi a juama moko boncianla.
22 Jesu sì dáhùn ó wí fún wọn pé, “Ẹ padà lọ, ẹ ròyìn nǹkan tí ẹ̀yin rí, tí ẹ̀yin sì gbọ́ fún Johanu: àwọn afọ́jú ń ríran, àwọn amúnkùn ún rìn, a sọ àwọn adẹ́tẹ̀ di mímọ́, àwọn adití ń gbọ́rọ̀, a ń jí àwọn òkú dìde, àti fún àwọn òtòṣì ni à ń wàásù ìyìnrere.
O den goa ki yedi Jan tondiba: “Guani mani ki ban togidi Jan yin gba ki go nua yaala: A juama noadi, a waba cuoni, a gbaada ŋanbidi, a woma gba, bi tinkpiba fiidi a luoda mo gba o laabaaliŋamo.
23 Alábùkún fún sì ni ẹnikẹ́ni tí kò kọsẹ̀ lára mi.”
Li pamanli ye leni min kaa tie yua yaapo tingbali bonla.”
24 Nígbà tí àwọn oníṣẹ́ Johanu padà lọ, ó bẹ̀rẹ̀ sí í sọ fún ìjọ ènìyàn ní ti Johanu pé, “Kí ni ẹ̀yin jáde lọ sí ijù lọ wò? Ewéko tí afẹ́fẹ́ ń mì?
Jan tondiba n den ñani Jesu kani ya yogunu, o den maadi ku niligu Jan maama ki yedi: “Yi den gedi mi fanpienma po ki ban laa be? Yua n tie nani u faalu n liebi ya ñinmuagu bi?
25 Ṣùgbọ́n kín ni ẹ̀yin jáde lọ wò? Ọkùnrin tí a wọ̀ ní aṣọ fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́? Wò ó, àwọn tí á wọ̀ ní aṣọ ògo, tí wọ́n sì ń jayé, ń bẹ ní ààfin ọba!
To, yi nan den gedi ki ban laa be? Yua n bobi ti tiaŋandi bi? Diidi ki le mani yaaba n yie ti tiaŋandi wani ye bi badicianba diedi nni.
26 Ṣùgbọ́n kí ni ẹ̀yin jáde lọ wò? Wòlíì? Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ó sì ju wòlíì lọ!
Yi nan den li gedi ki baa le be? O sawalipualo bi? Yeni de, ama n waani yi ke yin ban laa yua cie ba sawalipualo.
27 Èyí yìí ni ẹni tí a ti kọ̀wé nítorí rẹ̀ pé: “‘Wò ó, èmi yóò rán oníṣẹ́ mi síwájú rẹ; ẹni tí yóò tún ọ̀nà rẹ ṣe níwájú rẹ.’
Wani yaapo yo ke li diani ki yedi: 'Diidi, n soani n tondo a liiga, ke wan ŋanbi a sanu.'
28 Mo wí fún yín nínú àwọn tí a bí nínú obìnrin, kò sí wòlíì tí ó pọ̀ ju Johanu Onítẹ̀bọmi lọ, ṣùgbọ́n ẹni tí ó kéré jùlọ ní ìjọba Ọlọ́run, ó pọ̀jù ú lọ.”
N go yedi yi ke pua n mali yua kuli, yua n cie Jan ki ye. Ama yua n wa ki cie bi kuli U Tienu diema nni, wani n yaba ki cie o.
29 (Gbogbo àwọn ènìyàn tí ó gbọ́ àti àwọn agbowó òde, wọ́n dá Ọlọ́run láre, nítorí tí a fi ìtẹ̀bọmi Johanu tẹ̀ wọn bọ mi.
Ya niba n den cengi o kuli leni bi lubigaaba kuli den saa U Tienu po moamoani ki cedi ke Jan batisi ba.
30 Ṣùgbọ́n àwọn Farisi àti àwọn amòfin kọ ète Ọlọ́run fún ara wọn, a kò bamitiisi wọn lọ́dọ̀ rẹ̀.)
Ama Falisieninba leni li balimaama bangikaaba n den yie ke Jan kan batisi ba yeni, bi den yie U Tienu n den jagi ki bili bipo yaala.”
31 Jesu sì wí pé, “Kí ni èmi ìbá fi àwọn ènìyàn ìran yìí wé? Kí ni wọ́n sì jọ?
Jesu den pugini ki yedi: “N baa nandi moala na nuba leni be? Bi naani leni be?
32 Wọ́n dàbí àwọn ọmọ kékeré tí ó jókòó ní ibi ọjà, tí wọ́n sì ń kọ sí ara wọn, tí wọ́n sì ń wí pé, “‘Àwa fọn fèrè fún yín, ẹ̀yin kò jó, àwa sì ṣọ̀fọ̀ fún yín, ẹ̀yin kò sọkún!’
Bi naani leni ya bila n ka ki daaga nni ki yi bi yaba ki tua: 'Ti piebi yipo mu yelimu, ke yii jeli ki ciaga. Ti yiini yipo i kuyani, yi naa buudi.'
33 Nítorí Johanu Onítẹ̀bọmi wá, kò jẹ àkàrà, bẹ́ẹ̀ ni kò sì mu ọtí wáìnì, ẹ̀yin sì wí pé, ‘Ó ní ẹ̀mí èṣù?’
Kelima Jan Batisi cua, waa di jiema, waa ñu duven mo, ke yi tua: 'O pia ki cicibiadiga.'
34 Ọmọ ènìyàn dé, ó ń jẹ, ó sì ń mu, ẹ̀yin sì wí pé, ‘Wò ó, ọ̀jẹun, àti ọ̀mùtí, ọ̀rẹ́ àwọn agbowó òde àti àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀!’
O Joa Bijua mo cua ki di ki go ñu ke yi tua: 'Diidi ki le, O tie jiejiedo leni dañolo, ki ti bi lubigaaba leni i tagibiadi danba kuli ya danli.'
35 Ṣùgbọ́n ọgbọ́n ni a dá láre nípasẹ̀ ọmọ rẹ.”
Yaaba n tuo U Tienu yanfuoma kuli saa i moamoani ke mi tiegi.”
36 Farisi kan sì rọ̀ ọ́ kí ó wá bá òun jẹun, ó sì wọ ilé Farisi náà lọ ó sì jókòó láti jẹun.
Falisieninba siiga yendo den yini Jesu wan je leni o. Jesu den kua o diegu nni ki kali u saajekaanu kani.
37 Sì kíyèsi i, obìnrin kan wà ní ìlú náà, ẹni tí i ṣe ẹlẹ́ṣẹ̀, nígbà tí ó mọ̀ pé Jesu jókòó, ó ń jẹun ní ilé Farisi, ó mú ṣágo kékeré alabasita òróró ìkunra wá,
O pua den ye u dogu nni ke o tagu bia. Wan den bandi ke Jesu ye Falisieni yeni deni ki di, o den taa ya tanli n yi alibati ya buteliga ke gbie leni tulale,
38 Ó sì dúró tì í lẹ́bàá ẹsẹ̀ rẹ̀ lẹ́yìn, ó ń sọkún, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí i fi omijé wẹ̀ ẹ́ ní ẹsẹ̀, ó sì ń fi irun orí rẹ nù ún nù, ó sì ń fi ẹnu kò ó ní ẹsẹ̀, ó sì ń fi òróró kùn wọ́n.
ki cua ki sedi Jesu puoli po o taana kani ke o kpaagi li bonkalikaala po. O pua yeni den buudi ke o ninsiidi cuudi ki soangi Jesu taana ke o duuni a leni o yudi ki waliti a ki suogi a tulale.
39 Nígbà tí Farisi tí ó pè é sì rí i, ó wí nínú ara rẹ̀ pé, “Ọkùnrin yìí ìbá ṣe wòlíì, ìbá mọ ẹni àti irú ẹni tí obìnrin yìí jẹ́ tí ń fi ọwọ́ kàn an, nítorí ẹlẹ́ṣẹ̀ ni.”
Ya falisieni n den yini Jesu n den laa lani, o den yedi o yama nni: “One ya bi tie sawalipualo moamoani o bi baa bandi ya pua n sii o na n tie yua, leni o tagu n tie maama, ke o tie tagibiadu daano.”
40 Jesu sì dáhùn, ó wí fún un pé, “Simoni, Mo ní ohun kan sọ fún ọ.” Ó sì dáhùn pé, “Olùkọ́ máa wí.”
Lani Jesu den yedi Falisieni yeni: “Simono, n pia mi maama ki baa maadi a,” Simono den goa ki yedi o: “Canbaa, maadi.”
41 “Ayánilówó kan wà tí ó ní ajigbèsè méjì: ọ̀kan jẹ ẹ́ ní ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta owó idẹ, èkejì sì jẹ ẹ́ ní àádọ́ta.
Jesu den yedi o: “O pandinlo den ye ki pia pandanba lie. One den kubi opo kujapiena kobi muu, o lielo mo kujapiena piimuu.
42 Nígbà tí wọn kò sì ní ohun tí wọn ó san, ó dáríjì àwọn méjèèjì. Wí nínú àwọn méjèèjì, ta ni yóò fẹ́ ẹ jù?”
Ban kaa den pia liba ki baa pa, o den cabi bani niba lie yeni kuli bi pana. Bani niba lie yeni siiga, ŋme baa bua o ki cie o yua?”
43 Simoni dáhùn wí pé, “Mo ṣe bí ẹni tí ó dáríjì jù ni.” Jesu wí fún un pé, “Ìwọ ti dájọ́ náà dáradára.”
Simono den goa ki yedi o: “N tama wan cabi yua ke o panli yaba ki cie yene.” Jesu den yedi o: “A saa i moamoani.”
44 Ó sì yípadà sí obìnrin náà, ó wí fún Simoni pé, “Wo obìnrin yìí? Èmi wọ ilé rẹ, ìwọ kò fi omi wẹ ẹsẹ̀ fún mi: ṣùgbọ́n, omijé rẹ̀ ni ó fi ń rọ̀jò sí mi lẹ́sẹ̀ irun orí ni ó fi ń nù wọ́n nù.
Lani o den gbegi ki diidi o pua yeni ki go yedi Simono: “A laa o pua na? Min kua a dieli nni, ŋaa puni nni ñima ke n nigidi n taana, ama wani, o nigidi n taana leni o ninsiidi ki go duuni a leni o yudi.
45 Ìwọ kò fi ìfẹnukonu fún mi: ṣùgbọ́n òun, nígbà tí mo ti wọ ilé, kò dẹ́kun ẹnu fífi kò mí lẹ́sẹ̀.
Haa gobini nni leni mi buama, ama wani, ŋali min kua, o li waliti n taana yo, waa cedi.
46 Ìwọ kò fi òróró pa mí lórí, ṣùgbọ́n òun ti fi òróró pa mí lẹ́sẹ̀.
Haa wuli n yuli po kpama, ama wani, o suogi n taana leni tulale yua ya dunga n pa.
47 Ǹjẹ́ mo wí fún ọ, A dárí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ tí ó pọ̀ jì í: nítorí tí ó ní ìfẹ́ púpọ̀: ẹni tí a sì dárí díẹ̀ jì, òun náà ni ó ní ìfẹ́ díẹ̀.”
Lanyaapo n yedi a ke wan bua nni boncianla yeni doagidi ke o baa sugili o tuonbiadi yaadi n yaba po. Yua n baa sugili ya tuonbiadi n wa po mo bua waamu bebe.”
48 Ó sì wí fún un pé, “A dárí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ jì ọ́!”
O den yedi o pua mo: “A baa a tuonbiadi sugili.”
49 Àwọn tí ó bá a jókòó jẹun sì bẹ̀rẹ̀ sí í rò nínú ara wọn pé, “Ta ni èyí tí ń dárí ẹ̀ṣẹ̀ ji ni pẹ̀lú?”
Yaaba n den taani ki di leni o den maliti bi pala nni: “One tie ŋme ki puuni sugili ti tuonbiadi po?”
50 Ó sì dáhùn wí fún obìnrin náà pé, “Ìgbàgbọ́ rẹ gbà ọ́ là, máa lọ ní àlàáfíà.”
Jesu go den yedi o pua yeni: “A dandanli faabi a, fii ki ya caa leni mi yanduanma.”

< Luke 7 >