< Luke 6 >

1 Ní ọjọ́ ìsinmi kejì, Jesu ń kọjá láàrín oko ọkà; àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sì ń ya ìpẹ́ ọkà, wọ́n sì ń jẹ ẹ́.
Și s-a întâmplat în al doilea sabat după primul, că el trecea prin lanuri; și discipolii lui smulgeau spice, le frecau în mâini și mâncau.
2 Àwọn kan nínú àwọn Farisi sì wí fún wọn pé, “Ki lo de tí ẹ̀yin fi ń ṣe èyí tí kò yẹ láti ṣe ní ọjọ́ ìsinmi?”
Și unii dintre farisei le-au spus: De ce faceți ce nu este legiuit să faceți în sabate?
3 Jesu sì dá wọn lóhùn pé, “Ẹ̀yin kò kà nípa ohun tí Dafidi ṣe, nígbà tí ebi ń pa òun tìkára rẹ̀ àti àwọn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀;
Iar Isus, răspunzând, le-a zis: Nu ați citit deloc aceasta, ce a făcut David când a flămânzit el și cei ce erau cu el?
4 bi ó ti wọ ilé Ọlọ́run lọ, tí ó sì mú àkàrà ìfihàn tí ó sì jẹ ẹ́, tí ó sì fi fún àwọn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ pẹ̀lú; tí kò yẹ fún un láti jẹ, bí kò ṣe fún àwọn àlùfáà nìkan ṣoṣo?”
Cum a intrat în casa lui Dumnezeu și a luat și a mâncat pâinile punerii înainte și a dat și celor ce erau cu el; ceea ce nu este legiuit decât numai preoților să mănânce?
5 Ó sì wí fún wọn pé, “Ọmọ Ènìyàn ni Olúwa Ọjọ́ Ìsinmi.”
Și le-a spus: Fiul omului este Domn și al sabatului.
6 Ní ọjọ́ ìsinmi mìíràn, ó wọ inú Sinagọgu lọ, ó sì ń kọ́ni, ọkùnrin kan sì ń bẹ níbẹ̀ tí ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ rọ.
Și s-a întâmplat și în alt sabat, că a intrat în sinagogă și îi învăța; și acolo era un om a cărui mână dreaptă era uscată.
7 Àwọn akọ̀wé àti àwọn Farisi ń ṣọ́ ọ, bóyá yóò mú un láradá ní ọjọ́ ìsinmi; kí wọn lè rí ọ̀nà láti fi ẹ̀sùn kàn án.
Și scribii și fariseii îl pândeau, dacă va vindeca în sabat; ca să găsească o acuzație împotriva lui.
8 Ṣùgbọ́n ó mọ èrò inú wọn, ó sì wí fún ọkùnrin náà tí ọwọ́ rẹ̀ rọ pé, “Dìde, kí o sì dúró láàrín.” Ó sì dìde dúró.
Dar el le știa gândurile și a spus omului care avea mâna uscată: Ridică-te și stai în picioare în mijloc. Iar el s-a sculat și a stat în picioare.
9 Nígbà náà ni Jesu wí fún wọn pé, “Èmi bi yín léèrè, Ó ha tọ́ láti máa ṣe rere ni ọjọ́ ìsinmi, tàbí láti máa ṣe búburú? Láti gba ọkàn là, tàbí láti pa á run?”
Atunci Isus le-a spus: Vă voi întreba ceva. Este legiuit în sabate a face bine, ori a face rău? A salva viața sau a o nimici?
10 Nígbà tí ó sì wo gbogbo wọn yíká, ó wí fún ọkùnrin náà pé, “Na ọwọ́ rẹ.” Ó sì ṣe bẹ́ẹ̀: ọwọ́ rẹ̀ sì padà bọ̀ sípò gẹ́gẹ́ bí èkejì.
Și, uitându-se împrejur peste ei toți, a spus omului: Întinde-ți mâna. Iar el așa a făcut; și mâna lui a fost refăcută complet, ca cealaltă.
11 Wọ́n sì kún fún ìbínú gbígbóná; wọ́n sì bá ara wọn rò ohun tí àwọn ìbá ṣe sí Jesu.
Iar ei s-au umplut de nebunie; și au vorbit îndeaproape unii cu alții ce să îi facă lui Isus.
12 Ni ọ̀kan nínú àwọn ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, Jesu lọ sí orí òkè láti gbàdúrà, ó sì fi gbogbo òru náà gbàdúrà sí Ọlọ́run.
Și s-a întâmplat în zilele acelea, că el s-a dus pe un munte să se roage și a petrecut toată noaptea în rugăciune către Dumnezeu.
13 Nígbà tí ilẹ̀ sì mọ́, ó pe àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀; nínú wọn ni ó sì yan méjìlá, tí ó sì sọ ní aposteli:
Și când s-a făcut ziuă, a chemat la el pe discipolii săi; și dintre ei a ales doisprezece, pe care i-a numit și apostoli;
14 Simoni (ẹni tí a pè ní Peteru) àti Anderu arákùnrin rẹ̀, Jakọbu, Johanu, Filipi, Bartolomeu,
Pe Simon (pe care l-a numit și Petru) și pe Andrei, fratele lui; pe Iacov și pe Ioan, pe Filip și pe Bartolomeu;
15 Matiu, Tomasi, Jakọbu ọmọ Alfeu, Simoni tí a ń pè ní Sealoti,
Pe Matei și pe Toma; pe Iacov, fiul lui Alfeu, și pe Simon, numit Zelotes,
16 Judea arákùnrin Jakọbu, àti Judasi Iskariotu tí ó di ọ̀dàlẹ̀.
Pe Iuda, fratele lui Iacov; și pe Iuda Iscariot, care era și trădătorul.
17 Ó sì bá wọn sọ̀kalẹ̀, ó sì dúró ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, pẹ̀lú ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, àti ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn, láti gbogbo Judea, àti Jerusalẹmu, àti agbègbè Tire àti Sidoni, tí wọ́n wá láti gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀, àti láti gba ìmúláradá kúrò nínú ààrùn wọn;
Și el a coborât cu ei și a stat în picioare în câmp și mulțimea discipolilor lui și o mare mulțime de oameni din toată Iudeea și din Ierusalim și de pe lângă țărmul Tirului și al Sidonului, care au venit să îl audă și să fie vindecați de bolile lor,
18 àti àwọn tí ara wọn kún fún ẹ̀mí àìmọ́ ni ó sì mú láradá.
Și cei chinuiți de duhuri necurate și erau vindecați.
19 Gbogbo ìjọ ènìyàn sì ń fẹ́ láti fọwọ́ kàn án, nítorí tí àṣẹ ń jáde lára rẹ̀, ó sì mú gbogbo wọn láradá.
Și toată mulțimea căuta să îl atingă, pentru că din el ieșea o putere și îi vindeca pe toți.
20 Nígbà tí ó sì gbé ojú rẹ̀ sókè sí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, ó ní: “Alábùkún fún ni ẹ̀yin òtòṣì, nítorí tiyín ni ìjọba Ọlọ́run.
Și el și-a ridicat ochii spre discipolii săi și a spus: Binecuvântați sunteți voi, cei săraci, pentru că a voastră este împărăția lui Dumnezeu.
21 Alábùkún fún ni ẹ̀yin tí ebi ń pa nísinsin yìí; nítorí tí ẹ ó yóò. Alábùkún fún ni ẹ̀yin tí ń sọkún nísinsin yìí: nítorí tí ẹ̀yin ó rẹ́rìn-ín.
Binecuvântați sunteți voi, care flămânziți acum, pentru că veți fi săturați. Binecuvântați sunteți voi, care plângeți acum, pentru că veți râde.
22 Alábùkún fún ni ẹ̀yin, nígbà tí àwọn ènìyàn bá kórìíra yín, tí wọ́n bá yà yín kúrò nínú ẹgbẹ́ wọn, tí wọ́n bá gàn yín, tí wọ́n bá ta orúkọ yín nù bí ohun búburú, nítorí Ọmọ Ènìyàn.
Binecuvântați sunteți voi, când oamenii vă vor urî și când vă vor exclude și vă vor ocărî și vor lepăda numele vostru ca rău, datorită Fiului omului.
23 “Ẹ jẹ́ kí inú yín dùn, kí ẹ sì fò fún ayọ̀, nítorí púpọ̀ ní èrè yín ni ọ̀run. Báyìí ni àwọn baba yín ṣe ṣe sí àwọn wòlíì.
Bucurați-vă în acea zi și săltați de veselie; căci iată, răsplata voastră este mare în cer; fiindcă tot așa au făcut părinții lor cu profeții.
24 “Ègbé ni fún ẹ̀yin ọlọ́rọ̀ nítorí ẹ ti gba ìtùnú yín.
Dar vai vouă, care sunteți bogați! Pentru că v-ați primit mângâierea.
25 Ègbé ni fún ẹ̀yin tí ó yó, nítorí ebi yóò pa yín, Ègbé ni fún ẹ̀yin tí ń rẹ́rìn-ín nísinsin yìí, nítorí tí ẹ̀yin ó ṣọ̀fọ̀, ẹ̀yin ó sì sọkún.
Vai vouă, care sunteți sătui! Pentru că veți flămânzi. Vai vouă, care râdeți acum! Pentru că veți jeli și veți plânge.
26 Ègbé ni fún yín, nígbà tí gbogbo ènìyàn bá ń sọ̀rọ̀ yín ní rere, nítorí bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni àwọn baba wọn ṣe sí àwọn wòlíì èké.
Vai vouă, când toți oamenii vă vor vorbi de bine! Fiindcă astfel au făcut părinții lor cu profeții falși.
27 “Ṣùgbọ́n mo wí fún ẹ̀yin tí ń gbọ́ mi, ẹ fẹ́ àwọn ọ̀tá yín, ṣoore fún àwọn tí ó kórìíra yín.
Dar vă spun vouă care ascultați: Iubiți pe dușmanii voștri, faceți bine celor ce vă urăsc,
28 Súre fún àwọn tí ń fi yín ré, sì gbàdúrà fún àwọn tí ń kẹ́gàn yín.
Binecuvântați pe cei ce vă blestemă și rugați-vă pentru cei care vă folosesc cu dispreț.
29 Ẹni tí ó bá sì lù ọ́ ní ẹ̀rẹ̀kẹ́ kan, yí kejì sí i pẹ̀lú; àti ẹni tí ó gba agbádá rẹ, má ṣe dá a dúró láti gba ẹ̀wù àwọ̀tẹ́lẹ̀ rẹ pẹ̀lú.
Și celui ce te bate peste obraz, oferă-i și pe celălalt; și celui ce îți ia haina nu îi opri nici cămașa.
30 Sì fi fún gbogbo ẹni tí ó tọrọ lọ́dọ̀ rẹ; lọ́dọ̀ ẹni tí ó sì kó ọ ní ẹrù, má sì ṣe padà béèrè.
Și dă fiecăruia ce îți cere, și de la cel ce îți ia bunurile tale nu cere înapoi.
31 Gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin sì ti fẹ́ kí ènìyàn ṣe sí yín, kí ẹ̀yin sì ṣe bẹ́ẹ̀ sí wọn pẹ̀lú.
Și cum doriți să vă facă oamenii, faceți-le și voi la fel.
32 “Ǹjẹ́ bí ẹ̀yin bá fẹ́ àwọn tí ó fẹ́ yín, ọpẹ́ kí ni ẹ̀yin ní? Àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ pẹ̀lú ń fẹ́ àwọn tí ó fẹ́ wọn.
Și, dacă iubiți pe cei ce vă iubesc, ce mulțumire aveți voi? Fiindcă și păcătoșii iubesc pe cei ce îi iubesc.
33 Bí ẹ̀yin sì ṣoore fún àwọn tí ó ṣoore fún yín, ọpẹ́ kín ni ẹ̀yin ní? Àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ pẹ̀lú ń ṣe bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́.
Și dacă faceți bine celor ce vă fac bine, ce mulțumire aveți voi? Fiindcă și păcătoșii fac la fel.
34 Bí ẹ̀yin bá fi fún ẹni tí ẹ̀yin ń retí láti rí gbà padà, ọpẹ́ kín ni ẹ̀yin ní? Àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ pẹ̀lú ń yá ẹlẹ́ṣẹ̀, kí wọn lè gba ìwọ̀n bẹ́ẹ̀ padà.
Și dacă dați cu împrumut acelora de la care sperați să primiți înapoi, ce mulțumire aveți voi? Fiindcă și păcătoșii dau cu împrumut păcătoșilor, ca să primească înapoi cât au dat.
35 Ṣùgbọ́n kí ẹ̀yin fẹ́ àwọn ọ̀tá yín kí ẹ sì ṣoore, kí ẹ̀yin sì yá ẹlòmíràn, kí ẹ̀yin má ṣe retí láti rí nǹkan gbà padà; èrè yín yóò sì pọ̀, àwọn ọmọ Ọ̀gá-ògo ni a ó sì máa pè yín: nítorí tí ó ṣe rere fún aláìmoore àti fún ẹni búburú.
Totuși, iubiți pe dușmanii voștri și faceți bine și împrumutați fără să sperați nimic înapoi; și răsplata voastră va fi mare și veți fi copiii Celui Preaînalt; fiindcă el este bun cu cei nemulțumitori și cu cei răi.
36 Ǹjẹ́ kí ẹ̀yin ní àánú, gẹ́gẹ́ bí Baba yín sì ti ní àánú.
De aceea fiți milostivi, precum și Tatăl vostru este milostiv.
37 “Ẹ má ṣe dá ni lẹ́jọ́, a kì yóò sì dá yín lẹ́jọ́: ẹ má ṣe dá ni lẹ́bi, a kì yóò sì dá yín lẹ́bi: ẹ dáríjì, a ó sì dáríjì yín.
Nu judecați și nu veți fi judecați; nu condamnați și nu veți fi condamnați; iertați și veți fi iertați;
38 Ẹ fi fún ni, a ó sì fi fún yín; òsùwọ̀n dáradára, àkìmọ́lẹ̀, àti àmìpọ̀, àkúnwọ́sílẹ̀, ni a ó wọ́n si àyà yín: nítorí òsùwọ̀n náà tí ẹ̀yin fi wọ́n, òun ni a ó padà fi wọ́n fún yín.”
Dați și vi se va da; o măsură bună, îndesată și scuturată și vărsându-se pe deasupra, oamenii vă vor turna în sân. Căci cu aceeași măsură cu care măsurați, vi se va măsura înapoi.
39 Ó sì pa òwe kan fún wọn wí pé, “Afọ́jú ha lè ṣe amọ̀nà afọ́jú bí? Àwọn méjèèjì kọ́ ni yóò ṣubú sínú ihò bí?
Și le-a spus o parabolă: Poate orbul să călăuzească pe orb? Nu vor cădea amândoi în groapă?
40 Ẹni tí a ń kọ́ kì í ju olùkọ́ rẹ̀ lọ: ṣùgbọ́n olúkúlùkù ẹni tí a bá kọ dáradára, yóò dàbí olùkọ́ rẹ̀.
Discipolul nu este mai presus de învățătorul lui; dar fiecare discipol desăvârșit va fi ca învățătorul lui.
41 “Èétiṣe tí ìwọ fi ń wo ẹ̀rún igi tí ń bẹ ní ojú arákùnrin rẹ, ṣùgbọ́n ìwọ kò kíyèsi ìtì igi tí ń bẹ ní ojú ara rẹ?
Și de ce vezi tu paiul din ochiul fratelui tău și nu iei în considerare bârna din propriul tău ochi?
42 Tàbí ìwọ ó ti ṣe lè wí fún arákùnrin rẹ pé, ‘Arákùnrin, jẹ́ kí èmi yọ ẹ̀rún igi tí ń bẹ lójú rẹ,’ nígbà tí ìwọ tìkára rẹ kò kíyèsi ìtì igi tí ń bẹ lójú rẹ? Ìwọ àgàbàgebè, kọ́kọ́ yọ ìtí igi jáde kúrò lójú ara rẹ ná, nígbà náà ni ìwọ ó sì tó ríran gbangba láti yọ èérún igi tí ń bẹ lójú arákùnrin rẹ kúrò.
Sau cum poți spune fratelui tău: Frate, lasă-mă să scot paiul care este în ochiul tău, pe când, tu însuți nu vezi bârna care este în propriul tău ochi? Fățarnicule, scoate întâi bârna din propriul tău ochi și atunci vei vedea clar să scoți paiul care este în ochiul fratelui tău.
43 “Nítorí igi rere kì í so èso búburú; bẹ́ẹ̀ ni igi búburú kì í so èso rere.
Fiindcă un pom bun nu face rod stricat; niciun pom stricat nu face rod bun.
44 Olúkúlùkù igi ni a ń fi èso rẹ̀ mọ̀ ọn; nítorí lórí ẹ̀gún òṣùṣú, ènìyàn kì í ká èso ọ̀pọ̀tọ́ bẹ́ẹ̀ ni lórí ẹ̀gún ọ̀gàn a kì í ká èso àjàrà.
Fiindcă fiecare pom este cunoscut după rodul lui. Fiindcă nu se strâng smochine din spini, nici nu se adună struguri din mărăcini.
45 Ènìyàn rere láti inú yàrá ìṣúra rere ọkàn rẹ̀ ní mú ohun rere jáde wá; àti ènìyàn búburú láti inú ìṣúra búburú ọkàn rẹ̀ ní í mú ohun búburú jáde wá: nítorí láti inú ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ọkàn ní ẹnu ti máa sọ jáde.
Un om bun, din tezaurul bun al inimii lui, scoate ce este bun; și un om rău, din tezaurul rău al inimii lui scoate ce este rău; fiindcă din abundența inimii vorbește gura lui.
46 “Nítorí náà, èéṣe tí ẹ̀yin ń pè mí ní, ‘Olúwa, Olúwa,’ tí ẹ̀yin kò sì ṣe ohun tí mo wí?
Dar de ce mă chemați: Doamne, Doamne și nu faceți cele ce [vă] spun?
47 Ẹnikẹ́ni tí ó tọ̀ mí wá, tí ó sì ń gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, tí ó sì ń ṣe é, èmi yóò fi ẹni tí ó jọ hàn yín.
Oricine vine la mine și aude cuvintele mele și le face, vă voi arăta cu cine se aseamănă;
48 Ó jọ ọkùnrin kan, tí ó kọ́ ilé, tí ó sì wa ilẹ̀ jìn, tí ó sì fi ìpìlẹ̀ sọlẹ̀ lórí àpáta, nígbà tí kíkún omi sì dé, ìgbì omi kọlu ilé náà, kò sì lè mì ín nítorí tí a fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ sọlẹ̀ lórí àpáta.
Este asemenea unui om care a zidit o casă și a săpat adânc și a așezat temelia pe o stâncă; și când a venit potopul, șuvoiul a bătut violent peste casa aceea și nu a putut să o clatine, pentru că a fost fondată pe stâncă.
49 Ṣùgbọ́n ẹni tí ó gbọ́, tí kò sì ṣe é, ó dàbí ọkùnrin tí ó kọ́ ilé sí orí ilẹ̀ láìní ìpìlẹ̀; nígbà tí ìgbì omi kọlù ú, lọ́gán, ó sì wó; wíwó ilé náà sì pọ̀ púpọ̀.”
Dar cel ce aude și nu face, este asemenea unui om care, fără temelie, a zidit o casă pe pământ, împotriva căreia șuvoiul a bătut violent și imediat a căzut; și ruina acelei case a fost mare.

< Luke 6 >