< Luke 6 >

1 Ní ọjọ́ ìsinmi kejì, Jesu ń kọjá láàrín oko ọkà; àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sì ń ya ìpẹ́ ọkà, wọ́n sì ń jẹ ẹ́.
ⲁ̅ⲁⲥϣⲱⲡⲓ ⲇⲉ ⲧⲁϥⲥⲓⲛⲓ ϧⲉⲛ ⲛⲓⲥⲁⲃⲃⲁⲧⲟⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲟⲧⲟⲩ ⳿ⲛⲛⲓⲣⲟϯ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁⲣⲉ ⲛⲉϥⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ ϥⲱϫⲓ ⳿ⲛⲛⲓϧⲉⲙⲥ ⲉⲩⲥⲁϩⲥⲁϩ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ϧⲉⲛ ⲛⲟⲩϫⲓϫ ⲟⲩⲟϩ ⲩⲟⲩⲱⲙ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ.
2 Àwọn kan nínú àwọn Farisi sì wí fún wọn pé, “Ki lo de tí ẹ̀yin fi ń ṣe èyí tí kò yẹ láti ṣe ní ọjọ́ ìsinmi?”
ⲃ̅ϩⲁⲛⲟⲩⲟⲛ ⲇⲉ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲛⲓⲫⲁⲣⲓⲥⲉⲟⲥ ⲡⲉϫⲱⲟⲩ ϫⲉ ⲉⲑⲃⲉⲟⲩ ⲧⲉⲧⲉⲛ⳿ⲓⲣⲓ ⳿ⲙⲡⲉⲧⲥⲉ⳿ⲙ⳿ⲡϣⲁ ⳿ⲛⲁⲓϥ ⲁⲛ ϧⲉⲛ ⲛⲓⲥⲁⲃⲃⲁⲧⲟⲛ.
3 Jesu sì dá wọn lóhùn pé, “Ẹ̀yin kò kà nípa ohun tí Dafidi ṣe, nígbà tí ebi ń pa òun tìkára rẹ̀ àti àwọn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀;
ⲅ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁϥⲉⲣⲟⲩⲱ ⳿ⲛϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ⲟⲩⲇⲉ ⲫⲁⲓ ⳿ⲙⲡⲉⲧⲉⲛⲟϣϥ ⲫⲏⲉⲧⲁ ⲇⲁⲩⲓⲇ ⲁⲓϥ ϩⲟⲧⲉ ⲉⲧⲁϥ⳿ϩⲕⲟ ⲛⲉⲙ ⲛⲏⲉⲑⲛⲉⲙⲁϥ.
4 bi ó ti wọ ilé Ọlọ́run lọ, tí ó sì mú àkàrà ìfihàn tí ó sì jẹ ẹ́, tí ó sì fi fún àwọn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ pẹ̀lú; tí kò yẹ fún un láti jẹ, bí kò ṣe fún àwọn àlùfáà nìkan ṣoṣo?”
ⲇ̅ⲡⲱⲥ ⲁϥϣⲉ ⲛⲁϥ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉ⳿ⲡⲏⲓ ⳿ⲙⲫϯ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲓⲱⲓⲕ ⳿ⲛⲧⲉ ϯ⳿ⲡⲣⲟⲑⲉⲥⲓⲥ ⲁϥϭⲓⲧⲟⲩ ⲁϥⲟⲩⲟⲙⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥϯ ⳿ⲛⲛⲓⲕⲉⲭⲱⲟⲩⲛⲓ ⲉⲑⲛⲉⲙⲁϥ ⲛⲏ ⲧⲉⲛ⳿ⲥϣⲉ ⲛⲱⲟⲩ ⲁⲛ ⳿ⲉⲟⲩⲟⲙⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲏⲗ ⳿ⲉⲛⲓⲟⲩⲏⲃ ⳿ⲙⲙⲁⲩⲁⲧⲟⲩ.
5 Ó sì wí fún wọn pé, “Ọmọ Ènìyàn ni Olúwa Ọjọ́ Ìsinmi.”
ⲉ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁϥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ Ⲡ⳪ ⳿ⲙⲡⲓⲥⲁⲃⲃⲁⲧⲟⲛ ⲡⲉ ⳿ⲡϣⲏⲣⲓ ⲙ⳿ⲫⲣⲱⲙⲓ.
6 Ní ọjọ́ ìsinmi mìíràn, ó wọ inú Sinagọgu lọ, ó sì ń kọ́ni, ọkùnrin kan sì ń bẹ níbẹ̀ tí ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ rọ.
ⲋ̅ⲁⲥϣⲱⲡⲓ ⲇⲉ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲕⲉⲥⲁⲃⲃⲁⲧⲟⲛ ⲁϥϣⲉ ⲛⲁϥ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉⲧⲟⲩⲥⲩⲛⲁⲅⲱⲅⲏ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥ ϯ⳿ⲥⲃⲱ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲉ ⲟⲩⲟⲛ ⲟⲩⲣⲱⲙⲓ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲉ ⲉⲣⲉ ⲧⲉϥϫⲓϫ ⳿ⲛⲟⲩ⳿ⲓⲛⲁⲙ ϣⲟⲩ⳿ⲱⲟⲩ.
7 Àwọn akọ̀wé àti àwọn Farisi ń ṣọ́ ọ, bóyá yóò mú un láradá ní ọjọ́ ìsinmi; kí wọn lè rí ọ̀nà láti fi ẹ̀sùn kàn án.
ⲍ̅ⲛⲁⲩϯ⳿ⲛⲓⲁⲧⲟⲩ ⲛⲁϥ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲓⲥⲁϧ ⲛⲉⲙ ⲛⲓⲫⲁⲣⲓⲥⲉⲟⲥ ϫⲉ ⲁⲛ ⳿ϥⲛⲁⲉⲣⲫⲁϧⲣⲓ ϧⲉⲛ ⳿ⲡⲥⲁⲃⲃⲁⲧⲟⲛ ϩⲓⲛⲁ ⲛⲧⲟⲩϫⲉⲙ ⲕⲁⲧⲏⲅⲟⲣⲓ⳿ⲁ ϧⲁⲣⲟϥ.
8 Ṣùgbọ́n ó mọ èrò inú wọn, ó sì wí fún ọkùnrin náà tí ọwọ́ rẹ̀ rọ pé, “Dìde, kí o sì dúró láàrín.” Ó sì dìde dúró.
ⲏ̅⳿ⲛⲑⲟϥ ⲇⲉ ⲛⲁϥ⳿ⲉⲙⲓ ⳿ⲉⲛⲟⲩⲙⲟⲕⲙⲉⲕ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲱⲟⲩ ⳿ⲙⲡⲓⲣⲱⲙⲓ ⳿ⲉⲛⲁⲣⲉ ⲧⲉϥϫⲓϫ ϣⲟⲩ⳿ⲱⲟⲩ ϫⲉ ⲧⲱⲛⲕ ϩⲓ ⲉⲣⲁⲧⲕ ϧⲉⲛ ⳿ⲑⲙⲏϯ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥⲧⲱⲛϥ ⲁϥⲟϩⲓ ⳿ⲉⲣⲁⲧϥ.
9 Nígbà náà ni Jesu wí fún wọn pé, “Èmi bi yín léèrè, Ó ha tọ́ láti máa ṣe rere ni ọjọ́ ìsinmi, tàbí láti máa ṣe búburú? Láti gba ọkàn là, tàbí láti pa á run?”
ⲑ̅ⲡⲉϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ϯϣⲓⲛⲓ ⳿ⲙⲙⲱⲧⲉⲛ ϫⲉ ⲁⲛ ⳿ⲥϣⲉ ⳿ⲛⲉⲣ ⲡⲉⲑⲛⲁⲛⲉϥ ϧⲉⲛ ⲓⲥⲁⲃⲃⲁⲧⲟⲛ ϣⲁⲛ ⳿ⲉⲉⲣ ⲡⲉⲧϩⲱⲟⲩ ⲟⲩⲯⲩⲭⲏ ⳿ⲉⲛⲁϩⲙⲉⲥ ϣⲁⲛ ⳿ⲉⲧⲁⲕⲟⲥ.
10 Nígbà tí ó sì wo gbogbo wọn yíká, ó wí fún ọkùnrin náà pé, “Na ọwọ́ rẹ.” Ó sì ṣe bẹ́ẹ̀: ọwọ́ rẹ̀ sì padà bọ̀ sípò gẹ́gẹ́ bí èkejì.
ⲓ̅ⲟⲩⲟϩ ⲉⲧⲁϥϫⲟⲩϣⲧ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⲡⲉϫⲁϥ ⳿ⲙⲡⲓⲣⲱⲙⲓ ϫⲉ ⲟⲩⲧⲉⲛ ⲧⲉⲕϫⲓϫ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛⲑⲟϥ ⲇⲉ ⲁϥⲥⲟⲩⲧⲱⲛⲥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲥⲟⲩϫⲁⲓ ⳿ⲛϫⲉ ⲧⲉϥϫⲓϫ.
11 Wọ́n sì kún fún ìbínú gbígbóná; wọ́n sì bá ara wọn rò ohun tí àwọn ìbá ṣe sí Jesu.
ⲓ̅ⲁ̅⳿ⲛⲑⲱⲟⲩ ⲇⲉ ⲁⲩⲙⲟϩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲩⲙⲉⲧⲁⲧⲕⲁϯ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁⲩⲥⲁϫⲓ ⲛⲉⲙ ⲛⲟⲩ⳿ⲉⲣⲏⲟⲩ ϫⲉ ⲟⲩ ⲡⲉⲧⲟⲩⲛⲁⲁⲓϥ ⳿ⲛⲒⲏ̅ⲥ̅.
12 Ni ọ̀kan nínú àwọn ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, Jesu lọ sí orí òkè láti gbàdúrà, ó sì fi gbogbo òru náà gbàdúrà sí Ọlọ́run.
ⲓ̅ⲃ̅ⲁⲥϣⲱⲡⲓ ⲇⲉ ϧⲉⲛ ⲛⲓ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲁϥ⳿ⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲡⲓⲧⲱⲟⲩ ⲉⲉⲣ⳿ⲡⲣⲟⲥⲉⲩⲭ ⲉⲥⲑⲉ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁϥⲟⲓ ⳿ⲛ⳿ϣⲣⲱⲓⲥ ϧⲉⲛ ϯ ⳿ⲡⲣⲟⲥⲉⲩⲭⲏ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ.
13 Nígbà tí ilẹ̀ sì mọ́, ó pe àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀; nínú wọn ni ó sì yan méjìlá, tí ó sì sọ ní aposteli:
ⲓ̅ⲅ̅ⲟⲩⲟϩ ⲉⲧⲁ ⲡⲓ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ϣⲱⲡⲓ ⲁϥⲙⲟⲩϯ ⳿ⲉⲛⲉϥⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ ⲩⲟϩ ϥⲥⲱⲧⲡ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛϧⲏ ⲧⲟⲩ ⳿ⲙⲓ̅ⲃ̅ ⲛⲏⲉⲧⲁϥϯⲣⲉⲛⲟⲩ ϫⲉ ⲁⲡⲟⲥⲧⲟⲗⲟⲥ.
14 Simoni (ẹni tí a pè ní Peteru) àti Anderu arákùnrin rẹ̀, Jakọbu, Johanu, Filipi, Bartolomeu,
ⲓ̅ⲇ̅ⲥⲓⲙⲱⲛ ⲫⲏⲉⲧⲟⲩⲙⲟⲩϯ ⳿ⲉⲣⲟϥ ϫⲉ ⲡⲉⲧⲣⲟⲥ ⲛⲉⲙ ⲁⲛⲇⲣⲉⲁⲥ ⲁⲕⲱⲃⲟⲥ ⲛⲉⲙ ⲓⲱⲁⲛⲛⲏⲥ ⲫⲓⲗⲓⲡⲡⲟⲥ ⲛⲉⲙ ⲃⲁⲣⲑⲟⲗⲟⲙⲉⲟⲥ.
15 Matiu, Tomasi, Jakọbu ọmọ Alfeu, Simoni tí a ń pè ní Sealoti,
ⲓ̅ⲉ̅ⲛⲉⲙ ⲙⲁⲧⲑⲉⲟⲥ ⲛⲉⲙ ⲑⲱⲙⲁⲥ ⲛⲉⲙ ⲓⲁⲕⲱⲃⲟⲥ ⳿ⲛⲧⲉ ⲁⲗⲫⲉⲟⲥ ⲛⲉⲙ ⲥⲓⲙⲱⲛ ⲏ ⲉⲧⲟⲩⲙⲟⲩϯ ⳿ⲉⲣⲟϥ ϫⲉ ⲡⲓⲣⲉϥⲭⲟϩ.
16 Judea arákùnrin Jakọbu, àti Judasi Iskariotu tí ó di ọ̀dàlẹ̀.
ⲓ̅ⲋ̅ⲛⲉⲙ ⲓⲟⲩⲇⲁⲥ ⳿ⲛⲧⲉ ⲓⲁⲕⲱⲃⲟⲥ ⲛⲉⲙ ⲓⲟⲩⲇⲁⲥ ⲡⲓ⳿ⲥⲕⲁⲣⲓⲱⲧⲏⲥ.
17 Ó sì bá wọn sọ̀kalẹ̀, ó sì dúró ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, pẹ̀lú ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, àti ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn, láti gbogbo Judea, àti Jerusalẹmu, àti agbègbè Tire àti Sidoni, tí wọ́n wá láti gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀, àti láti gba ìmúláradá kúrò nínú ààrùn wọn;
ⲓ̅ⲍ̅ⲟⲩⲟϩ ⲉⲧⲁϥ⳿ⲓ ⳿ⲉ⳿ϧⲣⲏⲓ ⲛⲉⲙⲱⲟⲩ ϥ⳿ⲟϩⲓ ⳿ⲉⲣⲁⲧϥ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲙⲁ⳿ⲛⲕⲟⲓ ⲛⲉⲙ ⲟⲩⲙⲏϣ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲉϥⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ ⲛⲉⲙ ⲕⲉⲙⲏϣ ⲉϥⲟϣ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓⲗⲁⲟⲥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ϯⲓⲟⲩⲇⲉ⳿ⲁ ⲧⲏⲣⲥ ⲛⲉⲙ ⲓⲗ̅ⲏ̅ⲙ̅ ⲛⲉⲙ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ϯⲡⲁⲣⲁⲗⲓ⳿ⲁ ⳿ⲛⲧⲉ ⲧⲩⲣⲟⲥ ⲛⲉⲙ ⳿ⲧⲥⲓⲇⲱⲛ ⲛⲏ⳿ⲉⲧⲁⲩ⳿ⲓ ⳿ⲉⲥⲱⲧⲉⲙ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲉϥⲧⲁⲗϭⲱⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⲛⲟⲩϣⲱⲛⲓ.
18 àti àwọn tí ara wọn kún fún ẹ̀mí àìmọ́ ni ó sì mú láradá.
ⲓ̅ⲏ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲏ⳿ⲉⲧⲁⲩ⳿ⲧϩⲉⲙⲕⲟ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲓⲡ̅ⲛ̅ⲁ̅ ⳿ⲛ⳿ⲁⲕⲁⲑⲁⲣⲧⲟⲛ ⲛⲁϥⲉⲣⲫⲁϧⲣⲓ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ.
19 Gbogbo ìjọ ènìyàn sì ń fẹ́ láti fọwọ́ kàn án, nítorí tí àṣẹ ń jáde lára rẹ̀, ó sì mú gbogbo wọn láradá.
ⲓ̅ⲑ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁⲣⲉ ⲡⲓⲙⲏϣ ⲧⲏⲣϥ ⲕⲱϯ ⳿ⲛⲥⲁ ϭⲓ ⲛⲉⲙⲁϥ ϫⲉ ⲟⲩⲏⲓ ⲁ⳿ⲥⲛⲏⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲛϫⲉ ⲟⲩϫⲟⲙ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁϥⲧⲁⲗϭⲟ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⲡⲉ.
20 Nígbà tí ó sì gbé ojú rẹ̀ sókè sí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, ó ní: “Alábùkún fún ni ẹ̀yin òtòṣì, nítorí tiyín ni ìjọba Ọlọ́run.
ⲕ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲑⲟϥ ⲉⲧⲁϥϥⲁⲓ ⳿ⲛⲛⲉϥⲃⲁⲗ ⳿ⲉ⳿ⲡϣⲱⲓ ⳿ⲉⲛⲉϥⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ ⲛⲁϥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲱⲟⲩ⳿ⲛⲓⲁⲧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲛⲓϩⲏⲕⲓ ϫⲉ ⲑⲱⲧⲉⲛ ⲧⲉ ϯⲙⲉⲧⲟⲩⲣⲟ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ.
21 Alábùkún fún ni ẹ̀yin tí ebi ń pa nísinsin yìí; nítorí tí ẹ ó yóò. Alábùkún fún ni ẹ̀yin tí ń sọkún nísinsin yìí: nítorí tí ẹ̀yin ó rẹ́rìn-ín.
ⲕ̅ⲁ̅ⲱⲟⲩ⳿ⲛⲓⲁⲧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲛⲏ ⲧϩⲟⲕⲉⲣ ϯⲛⲟⲩ ϫⲉ ⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁⲥⲓ ⲱⲟⲩ⳿ⲛⲓⲁⲧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲛⲏⲉⲧⲣⲓⲙⲓ ϯⲛⲟⲩ ϫⲉ ⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁⲥⲱⲃⲓ.
22 Alábùkún fún ni ẹ̀yin, nígbà tí àwọn ènìyàn bá kórìíra yín, tí wọ́n bá yà yín kúrò nínú ẹgbẹ́ wọn, tí wọ́n bá gàn yín, tí wọ́n bá ta orúkọ yín nù bí ohun búburú, nítorí Ọmọ Ènìyàn.
ⲕ̅ⲃ̅ⲱⲟⲩ⳿ⲛⲓⲁⲧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲉϣⲱⲡ ⲛⲧⲟⲩⲙⲉⲥⲧⲉ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲓⲣⲱⲙⲓ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲟⲩⲟⲩⲉⲧ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲟⲩϣⲉϣ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲟⲩϩⲓ ⲡⲉⲧⲉⲛⲣⲁⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⳿ⲛⲟⲩⲡⲉⲧϩⲱⲟⲩ ⲉⲑⲃⲉ ⳿ⲡϣⲏⲣⲓ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲱⲙⲓ.
23 “Ẹ jẹ́ kí inú yín dùn, kí ẹ sì fò fún ayọ̀, nítorí púpọ̀ ní èrè yín ni ọ̀run. Báyìí ni àwọn baba yín ṣe ṣe sí àwọn wòlíì.
ⲕ̅ⲅ̅ⲣⲁϣⲓ ϧⲉⲛ ⲡⲓ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲑⲉⲗⲏⲗ ϩⲏⲡⲡⲉ ⲅⲁⲣ ⲡⲉⲧⲉⲛⲃⲉⲭⲉ ⲟⲩⲛⲓϣϯ ⲡⲉ ⳿ⲛ⳿ϩⲣⲏⲓ ⲉⲛ ⳿ⲧⲫⲉ ⲛⲁⲓ ⲅⲁⲣ ⳿ⲉⲛⲁⲩ⳿ⲓⲣⲓ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⳿ⲛⲛⲓⲡⲣⲟⲫⲏⲧⲏⲥ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲟⲩⲓⲟϯ.
24 “Ègbé ni fún ẹ̀yin ọlọ́rọ̀ nítorí ẹ ti gba ìtùnú yín.
ⲕ̅ⲇ̅⳿ⲡⲗⲏⲛ ⲟⲩⲟⲓ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϧⲁ ⲛⲓⲣⲁⲙⲁ⳿ⲟ ϫⲉ ⲁⲣⲉⲧⲉⲛⲕⲏⲛ ⲉⲣⲉⲧⲉⲛϭⲓ ⲙⲡⲉⲧⲉⲛϯϩⲟ.
25 Ègbé ni fún ẹ̀yin tí ó yó, nítorí ebi yóò pa yín, Ègbé ni fún ẹ̀yin tí ń rẹ́rìn-ín nísinsin yìí, nítorí tí ẹ̀yin ó ṣọ̀fọ̀, ẹ̀yin ó sì sọkún.
ⲕ̅ⲉ̅ⲟⲩⲟⲓ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϧⲁ ⲛⲏⲉⲧⲥⲏⲟⲩ ϯⲛⲟⲩ ϫⲉ ⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁ⳿ϩⲕⲟ ⲟⲩⲟⲓ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϧⲁ ⲛⲏⲉⲧⲥⲱⲃⲓ ϯⲛⲟⲩ ϫⲉ ⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁⲉⲣϩⲏⲃⲓ ⲩⲟϩ ⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁⲣⲓⲙⲓ.
26 Ègbé ni fún yín, nígbà tí gbogbo ènìyàn bá ń sọ̀rọ̀ yín ní rere, nítorí bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni àwọn baba wọn ṣe sí àwọn wòlíì èké.
ⲕ̅ⲋ̅ⲟⲩⲟⲓ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⲉϣⲱⲡ ⲁⲩϣⲁⲛϫⲟⲥ ⳿ⲉⲣⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲓⲣⲱⲙⲓ ⲧⲏⲣⲟⲩ ϫⲉ ⲕⲁⲗⲱⲥ ⲛⲁⲓ ⲅⲁⲣ ⲟⲛ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲣⲏϯ ⳿ⲉⲛⲁⲩ⳿ⲓⲣⲓ ⲙⲙⲱⲟⲩ ⳿ⲛⲛⲓⲡⲣⲟⲫⲏⲧⲏⲥ ⳿ⲛⲛⲟⲩϫ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲟⲩⲓⲟϯ.
27 “Ṣùgbọ́n mo wí fún ẹ̀yin tí ń gbọ́ mi, ẹ fẹ́ àwọn ọ̀tá yín, ṣoore fún àwọn tí ó kórìíra yín.
ⲕ̅ⲍ̅ⲁⲗⲗⲁ ϯϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϧⲁ ⲛⲏⲉⲧⲥⲱⲧⲉⲙ ϫⲉ ⲙⲉⲛⲣⲉ ⲛⲉⲧⲉⲛϫⲁϫⲓ ⲁⲣⲓ ⲉⲑⲛⲁⲛⲉϥ ⳿ⲛⲛⲏⲉⲑⲙⲟⲥϯ ⳿ⲙⲙⲱⲧⲉⲛ.
28 Súre fún àwọn tí ń fi yín ré, sì gbàdúrà fún àwọn tí ń kẹ́gàn yín.
ⲕ̅ⲏ̅⳿ⲥⲙⲟⲩ ⳿ⲉⲛⲏⲉⲧⲥⲁϩⲟⲩ⳿ⲓ ⳿ⲉⲣⲱⲧⲉⲛ ⲧⲱⲃϩ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲛⲏⲉⲧϭⲟϫⲓ ⳿ⲛⲥⲁ ⲑⲏⲛⲟⲩ.
29 Ẹni tí ó bá sì lù ọ́ ní ẹ̀rẹ̀kẹ́ kan, yí kejì sí i pẹ̀lú; àti ẹni tí ó gba agbádá rẹ, má ṣe dá a dúró láti gba ẹ̀wù àwọ̀tẹ́lẹ̀ rẹ pẹ̀lú.
ⲕ̅ⲑ̅ⲫⲏⲉⲑⲛⲁϩⲓⲟⲩ⳿ⲓ ⲉⲛ ⲧⲁⲓⲟⲩⲟϫⲓ ⲭⲁ ϯⲭⲉϯ ϧⲁⲧⲟⲧϥ ⲟⲩⲟϩ ⲫⲏⲉⲑⲛⲁⲱⲗⲓ ⳿ⲙⲡⲉⲕ⳿ϩⲃⲟⲥ ⳿ⲙⲡⲉⲣⲧⲁϩⲛⲟ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲉⲱⲗⲓ ⳿ⲛⲧⲉⲕⲕⲉ⳿ϣⲑⲏ ⲛ.
30 Sì fi fún gbogbo ẹni tí ó tọrọ lọ́dọ̀ rẹ; lọ́dọ̀ ẹni tí ó sì kó ọ ní ẹrù, má sì ṣe padà béèrè.
ⲗ̅ⲟⲩⲟⲛ ⲇⲉ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲑⲛⲁⲉⲣⲉⲧⲓⲛ ⳿ⲙⲙⲟⲕ ⲙⲟⲓ ⲛⲁϥ ⲟⲩⲟϩ ⲫⲏⲉⲑⲛⲁⲉⲗ ⲛⲉⲧⲉⲛⲟⲩⲕ ⳿ⲙⲡⲉⲣϣⲁⲧϥ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ.
31 Gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin sì ti fẹ́ kí ènìyàn ṣe sí yín, kí ẹ̀yin sì ṣe bẹ́ẹ̀ sí wọn pẹ̀lú.
ⲗ̅ⲁ̅ⲟⲩⲟϩ ⲕⲁⲧⲁ⳿ⲫⲣⲏϯ ⲉⲧⲉⲧⲉⲛⲟⲩⲱϣ ⳿ⲛⲧⲟⲩ⳿ⲓⲣⲓ ⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲓⲣⲱⲙⲓ ⲁⲣⲓⲟⲩ⳿ⲓ ⲛⲱⲟⲩ ϩⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲣⲏϯ.
32 “Ǹjẹ́ bí ẹ̀yin bá fẹ́ àwọn tí ó fẹ́ yín, ọpẹ́ kí ni ẹ̀yin ní? Àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ pẹ̀lú ń fẹ́ àwọn tí ó fẹ́ wọn.
ⲗ̅ⲃ̅ⲟⲩⲟϩ ⲓⲥϫⲉ ⲁⲣⲉⲧⲉⲛⲛⲁⲙⲉⲛⲣⲉ ⲛⲏⲉⲑⲙⲉⲓ ⳿ⲙⲙⲱⲧⲉⲛ ⲁϣ ⲡⲉ ⲡⲉⲧⲉⲛ⳿ϩⲙⲟⲧ ⲕⲉ ⲁⲣ ⲛⲓⲕⲉⲣⲉϥⲉⲣⲛⲟⲃⲓ ⲁⲩⲙⲉⲓ ⳿ⲛⲛⲏⲉⲑⲙⲉⲓ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ.
33 Bí ẹ̀yin sì ṣoore fún àwọn tí ó ṣoore fún yín, ọpẹ́ kín ni ẹ̀yin ní? Àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ pẹ̀lú ń ṣe bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́.
ⲗ̅ⲅ̅ⲟⲩⲟϩ ⲉϣⲱⲡ ⲁⲣⲉⲧⲉⲛⲛⲁⲉⲣ ⲡⲉⲑⲛⲁⲛⲉϥ ⳿ⲛⲛⲏⲉⲧⲉⲣ ⲡⲉⲑⲛⲁⲛⲉϥ ⲛⲉⲙⲱⲧⲉⲛ ⲁϣ ⲡⲉ ⲡⲉⲧⲉⲛ⳿ϩⲙⲟⲧ ⲛⲓⲕⲉⲣⲉϥⲉⲣⲛⲟⲃⲓ ⲥⲉ⳿ⲓⲣⲓ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲣⲏϯ.
34 Bí ẹ̀yin bá fi fún ẹni tí ẹ̀yin ń retí láti rí gbà padà, ọpẹ́ kín ni ẹ̀yin ní? Àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ pẹ̀lú ń yá ẹlẹ́ṣẹ̀, kí wọn lè gba ìwọ̀n bẹ́ẹ̀ padà.
ⲗ̅ⲇ̅ⲟⲩⲟϩ ⲉϣⲱⲡ ⲁⲣⲉⲧⲉⲛϣⲁⲛⲉⲣⲇⲁⲛⲓⲍⲓⲛ ⳿ⲛϩⲁⲛⲟⲩⲟⲛ ⲉⲣⲉⲧⲉⲛϩⲉⲗⲡⲓⲥ ⳿ⲉϭⲓ ⳿ⲛⲧⲟⲧⲟⲩ ϣ ⲡⲉ ⲡⲉⲧⲉⲛ⳿ϩⲙⲟⲧ ⲛⲓⲕⲉⲣⲉϥⲉⲣⲛⲟⲃⲓ ϩⲱⲟⲩ ⲥⲉⲉⲣⲇⲁⲛⲓⲍⲓⲛ ⳿ⲛⲛⲓⲣⲉϥⲉⲣⲛⲟⲃⲓ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲟⲩϭⲓ ⳿ⲛⲧⲟⲧⲟⲩ ⳿ⲛⲧⲟⲩϣⲉⲃⲓⲱ.
35 Ṣùgbọ́n kí ẹ̀yin fẹ́ àwọn ọ̀tá yín kí ẹ sì ṣoore, kí ẹ̀yin sì yá ẹlòmíràn, kí ẹ̀yin má ṣe retí láti rí nǹkan gbà padà; èrè yín yóò sì pọ̀, àwọn ọmọ Ọ̀gá-ògo ni a ó sì máa pè yín: nítorí tí ó ṣe rere fún aláìmoore àti fún ẹni búburú.
ⲗ̅ⲉ̅⳿ⲡⲗⲏⲛ ⲙⲉⲛⲣⲉ ⲉⲧⲉⲛϫⲁϫⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲣⲓ ⲡⲉⲑⲛⲁⲛⲉϥ ⲛⲱⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲙⲟⲓ ⳿ⲛⲧⲉⲧⲉⲛⲉⲣⲁⲡⲉⲗⲡⲓⲍⲓⲛ ⲁⲛ ⳿ⲛ⳿ϩⲗⲓ ⲟⲩⲟϩ ⳿ϥⲛⲁϣⲱⲡⲓ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲉⲧⲉⲛⲃⲉⲭⲉ ⳿ⲉⲛⲁϣⲱϥ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲧⲉⲛⲛⲁϣⲱⲡⲓ ⳿ⲛϣⲏⲣⲓ ⳿ⲙⲡⲉⲧϭⲟⲥⲓ ϫⲉ ⳿ⲛⲑⲟϥ ⲟⲩⲭ̅ⲥ̅ ⲡⲉ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲛⲓⲁⲧ⳿ϩⲙⲟⲧ ⲛⲉⲙ ⲛⲓⲡⲟⲛⲏⲣⲟⲥ.
36 Ǹjẹ́ kí ẹ̀yin ní àánú, gẹ́gẹ́ bí Baba yín sì ti ní àánú.
ⲗ̅ⲋ̅ϣⲱⲡⲓ ⲉⲣⲉⲧⲉⲛⲟⲓ ⳿ⲛⲛⲁⲏⲧ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⳿ⲙⲡⲉⲧⲉⲛⲓⲱⲧ ⲉϥⲟⲓ ⳿ⲛⲛⲁⲏⲧ.
37 “Ẹ má ṣe dá ni lẹ́jọ́, a kì yóò sì dá yín lẹ́jọ́: ẹ má ṣe dá ni lẹ́bi, a kì yóò sì dá yín lẹ́bi: ẹ dáríjì, a ó sì dáríjì yín.
ⲗ̅ⲍ̅⳿ⲙⲡⲉⲣϯϩⲁⲡ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲛⲟⲩϯϩⲁⲡ ⳿ⲉⲣⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲙⲡⲉⲣϩⲓⲟⲩ⳿ⲓ ⳿ⲙ⳿ⲡϩⲁⲡ ⲟⲩⲟϩ ⲥⲉⲛⲁϩⲓ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⳿ⲙ⳿ⲡϩⲁⲡ ⲁⲛ ⲭⲱ ⲉⲃⲟⲗ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲟⲩⲭⲱ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗ.
38 Ẹ fi fún ni, a ó sì fi fún yín; òsùwọ̀n dáradára, àkìmọ́lẹ̀, àti àmìpọ̀, àkúnwọ́sílẹ̀, ni a ó wọ́n si àyà yín: nítorí òsùwọ̀n náà tí ẹ̀yin fi wọ́n, òun ni a ó padà fi wọ́n fún yín.”
ⲗ̅ⲏ̅ⲙⲟⲓ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲟⲩϯ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⲟⲩϣⲓ ⳿ⲉⲛⲁⲛⲉϥ ⲉϥⲙⲉϩ ⲉϥϩⲉⲛϩⲱⲛ ⲉϥⲫⲉⲛⲫⲱⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲥⲉⲛⲁⲧⲏⲓϥ ⲉ⳿ϧⲣⲏⲓ ⳿ⲉⲕⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲡⲓϣⲓ ⲅⲁⲣ ⲉⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁϣⲓ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲁⲩⲛⲁϣⲓ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲙⲙⲟϥ.
39 Ó sì pa òwe kan fún wọn wí pé, “Afọ́jú ha lè ṣe amọ̀nà afọ́jú bí? Àwọn méjèèjì kọ́ ni yóò ṣubú sínú ihò bí?
ⲗ̅ⲑ̅ⲁϥϫⲉ ⲕⲉⲡⲁⲣⲁⲃⲟⲗⲏ ⲇⲉ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ⲙⲏⲧⲓ ⲟⲩⲟⲛ ϣϫⲟⲙ ⳿ⲛⲟⲩⲃⲉⲗⲗⲉ ⳿ⲉϭⲓⲙⲱⲓⲧ ϧⲁϫⲱϥ ⳿ⲛⲟⲩⲃⲉⲗⲗⲉ ⲙⲏ ⲥⲉⲛⲁϩⲉⲓ ⲁⲛ ⳿ⲉ⳿ϧⲣⲏⲓ ⳿ⲛⲟⲩϣⲓⲕ ⳿ⲙ⳿ⲡⲃ̅.
40 Ẹni tí a ń kọ́ kì í ju olùkọ́ rẹ̀ lọ: ṣùgbọ́n olúkúlùkù ẹni tí a bá kọ dáradára, yóò dàbí olùkọ́ rẹ̀.
ⲙ̅ⲙⲏ ⲟⲩⲟⲛ ⲟⲩⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ ⲉϥⲟⲩⲟⲧ ⳿ⲉⲡⲉϥⲣⲉϥϯ⳿ⲥⲃⲱ ⲙⲁⲣⲉϥϣⲱⲡⲓ ⲇⲉ ⳿ⲛϫⲉ ⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲉϥⲥⲉⲃⲧⲱⲧ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⳿ⲙⲡⲓⲣⲉϥϯ⳿ⲥⲃⲱ.
41 “Èétiṣe tí ìwọ fi ń wo ẹ̀rún igi tí ń bẹ ní ojú arákùnrin rẹ, ṣùgbọ́n ìwọ kò kíyèsi ìtì igi tí ń bẹ ní ojú ara rẹ?
ⲙ̅ⲁ̅ⲉⲑⲃⲉⲟⲩ ϫⲉ ⳿ⲭⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲡⲓϫⲏⲓ ϧⲉⲛ ⳿ⲫⲃⲁⲗ ⳿ⲙⲡⲉⲕⲥⲟⲛ ⲡⲓⲥⲟⲓ ⲇⲉ ⲉⲧϧⲉⲛ ⲡⲉⲕⲃⲁⲗ ⳿ⲛ⳿ⲕϯ⳿ⲛⲓⲁⲧⲕ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲁⲛ.
42 Tàbí ìwọ ó ti ṣe lè wí fún arákùnrin rẹ pé, ‘Arákùnrin, jẹ́ kí èmi yọ ẹ̀rún igi tí ń bẹ lójú rẹ,’ nígbà tí ìwọ tìkára rẹ kò kíyèsi ìtì igi tí ń bẹ lójú rẹ? Ìwọ àgàbàgebè, kọ́kọ́ yọ ìtí igi jáde kúrò lójú ara rẹ ná, nígbà náà ni ìwọ ó sì tó ríran gbangba láti yọ èérún igi tí ń bẹ lójú arákùnrin rẹ kúrò.
ⲙ̅ⲃ̅ⲓⲉ ⲡⲱⲥ ⲟⲩⲟⲛ ⳿ϣϫⲟⲙ ⳿ⲙⲙⲟⲕ ⳿ⲉϫⲟⲥ ⳿ⲙⲡⲉⲕⲥⲟⲛ ϫⲉ ⲡⲁⲥⲟⲛ ⲭⲁⲧ ⳿ⲛⲧⲁϩⲓ ⲓϫⲏⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲡⲉⲕⲃⲁⲗ ⳿ⲛⲑⲟⲕ ⲇⲉ ϩⲱⲕ ⳿ⲭⲛⲁⲩ ⲁⲛ ⳿ⲉⲡⲓⲥⲟⲓ ⲉⲧϧⲉⲛ ⲡⲉⲕⲃⲁⲗ ⲡⲓϣⲟⲃⲓ ϩⲓ ⲡⲓⲥⲟⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲡⲉⲕⲃⲁⲗ ⳿ⲛϣⲟⲣⲡ ⲟⲩⲟϩ ⲧⲟⲧⲉ ⲉⲕ⳿ⲉⲛⲁⲩ ⳿ⲙⲃⲟⲗ ⳿ⲉϩⲓ ⲡⲓϫⲏⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⳿ⲫⲃⲁⲗ ⳿ⲙⲡⲉⲕⲥⲟⲛ.
43 “Nítorí igi rere kì í so èso búburú; bẹ́ẹ̀ ni igi búburú kì í so èso rere.
ⲙ̅ⲅ̅ⲟⲩ ⲅⲁⲣ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⲟⲩ⳿ϣϣⲏⲛ ⳿ⲉⲛⲁⲛⲉϥ ⲉϥ⳿ⲓⲣⲓ ⳿ⲛⲟⲩⲟⲩⲧⲁϩ ⲉϥϩⲱⲟⲩ ⲡⲁⲗⲓⲛ ⲙⲙⲟⲛ ⲟⲩ⳿ϣϣⲏⲛ ⲉϥϩⲱⲟⲩ ⲉϥ⳿ⲓⲣⲓ ⳿ⲛⲟⲩⲟⲩⲧⲁϩ ⳿ⲉⲛⲁⲛⲉϥ.
44 Olúkúlùkù igi ni a ń fi èso rẹ̀ mọ̀ ọn; nítorí lórí ẹ̀gún òṣùṣú, ènìyàn kì í ká èso ọ̀pọ̀tọ́ bẹ́ẹ̀ ni lórí ẹ̀gún ọ̀gàn a kì í ká èso àjàrà.
ⲙ̅ⲇ̅ⲡⲓⲟⲩⲁⲓ ⲅⲁⲣ ⲡⲓⲟⲩⲁⲓ ⳿ⲛⲛⲓ⳿ϣϣⲏⲛ ⲉϣⲁⲩⲥⲟⲩⲱⲛϥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲡⲉϥⲟⲩⲧⲁϩ ⲟⲩ ⲅⲁⲣ ⳿ⲙⲡⲁⲩⲥⲉⲕ ⲕⲉⲛⲧⲉ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ϩⲁⲛⲥⲟⲩⲣⲓ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲙⲡⲁⲩϭⲉⲗ ⳿ⲁⲗⲟⲗⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓ ⲟⲩⲃⲁⲧⲟⲥ.
45 Ènìyàn rere láti inú yàrá ìṣúra rere ọkàn rẹ̀ ní mú ohun rere jáde wá; àti ènìyàn búburú láti inú ìṣúra búburú ọkàn rẹ̀ ní í mú ohun búburú jáde wá: nítorí láti inú ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ọkàn ní ẹnu ti máa sọ jáde.
ⲙ̅ⲉ̅ⲡⲓⲁⲅⲁⲑⲟⲥ ⳿ⲛⲣⲱⲙⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲁϩⲟ ⳿ⲛⲁⲅⲁⲑⲟⲛ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲉϥϩⲏⲧ ϣⲁϥ⳿ⲓⲛⲓ ⳿ⲙⲡⲓⲁⲅⲁⲑⲟⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲟⲩⲟϩ ⲡⲓⲥⲁ⳿ⲙⲡⲉⲧϩⲱⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲁϩⲟ ⲉⲧϩⲱⲟⲩ ϣⲁϥⲓⲛⲓ ⳿ⲙⲡⲓⲡⲉⲧϩⲱⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⳿ⲡϩⲟⲩⲟ ⳿ⲙ⳿ⲡϩⲏⲧ ϣⲁⲣⲉ ⲡⲓⲣⲱϥ ⲥⲁϫⲓ.
46 “Nítorí náà, èéṣe tí ẹ̀yin ń pè mí ní, ‘Olúwa, Olúwa,’ tí ẹ̀yin kò sì ṣe ohun tí mo wí?
ⲙ̅ⲋ̅ⲉⲑⲃⲉⲟⲩ ⲇⲉ ⲧⲉⲧⲉⲛⲙⲟⲩϯ ⳿ⲉⲣⲟⲓ ϫⲉ Ⲡ⳪ Ⲡ⳪ ⲟⲩⲟϩ ⲧⲉⲧⲉⲛ⳿ⲓⲣⲓ ⲁⲛ ⳿ⲛⲛⲏ ⳿ⲉϯϫⲱ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ.
47 Ẹnikẹ́ni tí ó tọ̀ mí wá, tí ó sì ń gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, tí ó sì ń ṣe é, èmi yóò fi ẹni tí ó jọ hàn yín.
ⲙ̅ⲍ̅ⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲉⲑⲛⲁ⳿ⲓ ϩⲁⲣⲟⲓ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲉϥⲥⲱⲧⲉⲙ ⳿ⲉⲛⲁⲥⲁϫⲓ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲉϥⲁⲓⲧⲟⲩ ϯⲛⲁⲧⲁⲙⲱⲧⲉⲛ ϫⲉ ⲁϥⲧⲉⲛⲑⲱⲛⲧ ⳿ⲉⲛⲓⲙ.
48 Ó jọ ọkùnrin kan, tí ó kọ́ ilé, tí ó sì wa ilẹ̀ jìn, tí ó sì fi ìpìlẹ̀ sọlẹ̀ lórí àpáta, nígbà tí kíkún omi sì dé, ìgbì omi kọlu ilé náà, kò sì lè mì ín nítorí tí a fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ sọlẹ̀ lórí àpáta.
ⲙ̅ⲏ̅ⲁ ⲧⲉⲛⲑⲱⲛⲧ ⳿ⲉⲟⲩⲣⲱⲙⲓ ⲉϥⲕⲱⲧ ⳿ⲛⲟⲩⲏⲓ ⲫⲏⲉⲧⲁϥϫⲱϫⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥϣⲱⲕⲓ ⳿ⲉ⳿ϧⲣⲏⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥⲭⲱ ⳿ⲛⲟⲩⲥⲉⲛϯ ϩⲓϫⲉⲛ ϯⲡⲉⲧⲣⲁ ⲧⲁⲩϣⲱⲡⲓ ⲇⲉ ⳿ⲛϫⲉ ϩⲁⲛⲙⲟⲩ⳿ⲛϩⲱⲟⲩ ⲉⲩⲟϣ ⲁϥⲕⲱⲗϩ ⳿ⲛϫⲉ ⳿ⲡⲓⲁⲣⲟ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲛⲥⲁ ⲡⲓⲏⲓ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲙⲡⲉϥ⳿ϣϫⲉⲙϫⲟⲙ ⳿ⲛⲕⲓⲙ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⲉⲑⲃⲉϫⲉ ⲛⲁϥⲕⲏⲧ ⳿ⲛⲕⲁⲗⲱⲥ.
49 Ṣùgbọ́n ẹni tí ó gbọ́, tí kò sì ṣe é, ó dàbí ọkùnrin tí ó kọ́ ilé sí orí ilẹ̀ láìní ìpìlẹ̀; nígbà tí ìgbì omi kọlù ú, lọ́gán, ó sì wó; wíwó ilé náà sì pọ̀ púpọ̀.”
ⲙ̅ⲑ̅ⲫⲏ ⲇⲉ ⲉⲑⲛⲁⲥⲱⲧⲉⲙ ⳿ⲉⲛⲁⲥⲁϫⲓ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲉϥ⳿ϣⲧⲉⲙⲁⲓⲧⲟⲩ ⲁϥⲧⲉⲛⲑⲱⲛⲧ ⳿ⲉⲟⲩⲣⲱⲙⲓ ⳿ⲉⲁϥⲕⲱⲧ ⳿ⲛⲟⲩⲏⲓ ϩⲓϫⲉⲛ ⲓⲕⲁϩⲓ ⲭⲱⲣⲓⲥ ⲥⲉⲛϯ ⲫⲏⲉⲧⲁ ⲡⲓⲓⲁⲣⲟ ⲕⲱⲗϩ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⲟⲩⲟϩ ⲥⲁⲧⲟⲧϥ ⲁϥϩⲉⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲁ ⳿ⲡϩⲉⲓ ⳿ⲙⲡⲓⲏⲓ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲁϥⲉⲣⲟⲩⲛⲓϣϯ

< Luke 6 >