< Luke 6 >
1 Ní ọjọ́ ìsinmi kejì, Jesu ń kọjá láàrín oko ọkà; àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sì ń ya ìpẹ́ ọkà, wọ́n sì ń jẹ ẹ́.
Na iwa di lirin Nassabath na Yesu wadin cin nanya kunen ni leu acurmye wadin nkulu nati ni leu, ipara na cara mene ituna nlee.
2 Àwọn kan nínú àwọn Farisi sì wí fún wọn pé, “Ki lo de tí ẹ̀yin fi ń ṣe èyí tí kò yẹ láti ṣe ní ọjọ́ ìsinmi?”
Amon nanya na Farisiyawa woro, “Inyari ita idin nsu nilemong le na i caun isu liri na Sabbth ba?”
3 Jesu sì dá wọn lóhùn pé, “Ẹ̀yin kò kà nípa ohun tí Dafidi ṣe, nígbà tí ebi ń pa òun tìkára rẹ̀ àti àwọn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀;
Yesu kauwa nani a woro, “Na anung na karanta imung ile na Dauda wasu kube na wa lazan kukpong, ligowe nan nanit na iwa di nanghe?
4 bi ó ti wọ ilé Ọlọ́run lọ, tí ó sì mú àkàrà ìfihàn tí ó sì jẹ ẹ́, tí ó sì fi fún àwọn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ pẹ̀lú; tí kò yẹ fún un láti jẹ, bí kò ṣe fún àwọn àlùfáà nìkan ṣoṣo?”
Awa piru kilari Kutelle, ayira uburodi ule na iwa ceu a leu umon nanya ukuru ama alenge na imadi ligo we nan ghe un na priestari cas ile.”
5 Ó sì wí fún wọn pé, “Ọmọ Ènìyàn ni Olúwa Ọjọ́ Ìsinmi.”
Anin woro nani, “Gono nit Ucifari un na Sabath.”
6 Ní ọjọ́ ìsinmi mìíràn, ó wọ inú Sinagọgu lọ, ó sì ń kọ́ni, ọkùnrin kan sì ń bẹ níbẹ̀ tí ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ rọ.
Uda among Asabar na awa piru nanya kutii nlira adin dursuzu anite kikane umong unit wa diku nin ku girin cara.
7 Àwọn akọ̀wé àti àwọn Farisi ń ṣọ́ ọ, bóyá yóò mú un láradá ní ọjọ́ ìsinmi; kí wọn lè rí ọ̀nà láti fi ẹ̀sùn kàn án.
Anan niyert nang na Farisiyawa wadin yenju susut sa a ba shinu nin mung unan konu lirin na Sabath, inan se imong ile na inna Vuruzughe mung.
8 Ṣùgbọ́n ó mọ èrò inú wọn, ó sì wí fún ọkùnrin náà tí ọwọ́ rẹ̀ rọ pé, “Dìde, kí o sì dúró láàrín.” Ó sì dìde dúró.
Bara nani ayino ile imung na idin kpilizue nibinai myene a woron nle na ucara di kuger, “Fita, uyisin kitill nanite.” Unite fita a yisina kitene.
9 Nígbà náà ni Jesu wí fún wọn pé, “Èmi bi yín léèrè, Ó ha tọ́ láti máa ṣe rere ni ọjọ́ ìsinmi, tàbí láti máa ṣe búburú? Láti gba ọkàn là, tàbí láti pa á run?”
Yesu woro nani, natirin minu, ucaun isu imong icine liri na Sabatha sa isu inanzang i tucu ulai ya sa inanza unin?”
10 Nígbà tí ó sì wo gbogbo wọn yíká, ó wí fún ọkùnrin náà pé, “Na ọwọ́ rẹ.” Ó sì ṣe bẹ́ẹ̀: ọwọ́ rẹ̀ sì padà bọ̀ sípò gẹ́gẹ́ bí èkejì.
A yenje nani vat anin woro anite, “Nakpa ucara fe.” Ata nani ucara mye kpilaku.
11 Wọ́n sì kún fún ìbínú gbígbóná; wọ́n sì bá ara wọn rò ohun tí àwọn ìbá ṣe sí Jesu.
Bara nani ayi mine nana ilira nanya natimine, kitene nile imon na ibasu Yesu ku.
12 Ni ọ̀kan nínú àwọn ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, Jesu lọ sí orí òkè láti gbàdúrà, ó sì fi gbogbo òru náà gbàdúrà sí Ọlọ́run.
Uso nani, nanya nayiri ane a ghana kitene liikup asu nliran, a leo ubun nin kiitike vat nlira kiti Kutelle.
13 Nígbà tí ilẹ̀ sì mọ́, ó pe àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀; nínú wọn ni ó sì yan méjìlá, tí ó sì sọ ní aposteli:
Kubi na kiti nshanta, ayicila nono katuwa mye, a fere annit likure alenge tutung na iwa ni nani lissa “anan kadura.”
14 Simoni (ẹni tí a pè ní Peteru) àti Anderu arákùnrin rẹ̀, Jakọbu, Johanu, Filipi, Bartolomeu,
Tisa nanan kadura mye inughe Simon (ulenge na iwa nighe lisa Bitrus) nin gwana mye Andrawus, Yakubu, Yohanna, Filibus, Bartamalawus,
15 Matiu, Tomasi, Jakọbu ọmọ Alfeu, Simoni tí a ń pè ní Sealoti,
Matta, Tomas, Yakubu usaun Alfa, Simon, ulenge na idin yicughe Zaloti,
16 Judea arákùnrin Jakọbu, àti Judasi Iskariotu tí ó di ọ̀dàlẹ̀.
Yahuda usaun Yakubu, nin Yahuda Iskariyoti ulenge na aba lewughe.
17 Ó sì bá wọn sọ̀kalẹ̀, ó sì dúró ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, pẹ̀lú ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, àti ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn, láti gbogbo Judea, àti Jerusalẹmu, àti agbègbè Tire àti Sidoni, tí wọ́n wá láti gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀, àti láti gba ìmúláradá kúrò nínú ààrùn wọn;
Kube Yesu tolo kitene likupe nan ghinu ida yisina kiti kitendelen, ligozi na nan katuwa mye gbardang wa duku, nin ligozi nani gbardang na inuzu Nyahudiya nin Urushelima, nin nbui kurawa Sidoniya a Utaya.
18 àti àwọn tí ara wọn kún fún ẹ̀mí àìmọ́ ni ó sì mú láradá.
Iwa daka ida lanza ghe, ukuru ise ushinu nin tikonu mine, anit alenge na iwadi nniu nin nruhu unanzang iwa shinn.
19 Gbogbo ìjọ ènìyàn sì ń fẹ́ láti fọwọ́ kàn án, nítorí tí àṣẹ ń jáde lára rẹ̀, ó sì mú gbogbo wọn láradá.
Ko gha nanya ligoze wa dinin su a dudo ghe bara likara nshishinu vat.
20 Nígbà tí ó sì gbé ojú rẹ̀ sókè sí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, ó ní: “Alábùkún fún ni ẹ̀yin òtòṣì, nítorí tiyín ni ìjọba Ọlọ́run.
Ame yene anan katuwa mye a woro, “Anung anan nmariari ulenge na idi akimon, bara anughere anan kipin tigo Kutelle.
21 Alábùkún fún ni ẹ̀yin tí ebi ń pa nísinsin yìí; nítorí tí ẹ ó yóò. Alábùkún fún ni ẹ̀yin tí ń sọkún nísinsin yìí: nítorí tí ẹ̀yin ó rẹ́rìn-ín.
Anan nmariari unughe na idi lanzu kukpon nene, bara anug ba shittu, anan nmariari anughe na idi kuculu, bara iba su tisina.
22 Alábùkún fún ni ẹ̀yin, nígbà tí àwọn ènìyàn bá kórìíra yín, tí wọ́n bá yà yín kúrò nínú ẹgbẹ́ wọn, tí wọ́n bá gàn yín, tí wọ́n bá ta orúkọ yín nù bí ohun búburú, nítorí Ọmọ Ènìyàn.
Anan nmariari anughe asa anit nnari munu, kubi na ikoso ligo nan ghinu, isu munu nshina, inani nanza munu lisa nworo anug umuguari, bara upiziru lisa ngono nnit.
23 “Ẹ jẹ́ kí inú yín dùn, kí ẹ sì fò fún ayọ̀, nítorí púpọ̀ ní èrè yín ni ọ̀run. Báyìí ni àwọn baba yín ṣe ṣe sí àwọn wòlíì.
Suun liburi libo liyiri lole, inyizin bara ulanzu nmang, bara fe base uduk udia nanya kitene kani bara acif mine nanere iwa su anan kadura Kutelle.
24 “Ègbé ni fún ẹ̀yin ọlọ́rọ̀ nítorí ẹ ti gba ìtùnú yín.
Kash anung anang nimon nacara, barra imal seru uduk mine.
25 Ègbé ni fún ẹ̀yin tí ó yó, nítorí ebi yóò pa yín, Ègbé ni fún ẹ̀yin tí ń rẹ́rìn-ín nísinsin yìí, nítorí tí ẹ̀yin ó ṣọ̀fọ̀, ẹ̀yin ó sì sọkún.
Kash anung alenge na ishitin nene, bara kukpon ba da munu nin ndu nbun, kash anung na idi tisina. nene, iba su tiyom nin kuculu nin ndu nbun.
26 Ègbé ni fún yín, nígbà tí gbogbo ènìyàn bá ń sọ̀rọ̀ yín ní rere, nítorí bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni àwọn baba wọn ṣe sí àwọn wòlíì èké.
Kash anung alenge na anit di nliru gegeme kitene mine, bara acif wa su anan nliru kinu nin nnu Kutelle nanere.
27 “Ṣùgbọ́n mo wí fún ẹ̀yin tí ń gbọ́ mi, ẹ fẹ́ àwọn ọ̀tá yín, ṣoore fún àwọn tí ó kórìíra yín.
Bara nani meng di belle munu na idin lanzu, taan usu na nan nivira nanghinu, isu imon icine kiti nalenge na inari munu.
28 Súre fún àwọn tí ń fi yín ré, sì gbàdúrà fún àwọn tí ń kẹ́gàn yín.
Taan aleenge na itamunu unnu nmari, suun alenge na idin tumunu ineo nliran.
29 Ẹni tí ó bá sì lù ọ́ ní ẹ̀rẹ̀kẹ́ kan, yí kejì sí i pẹ̀lú; àti ẹni tí ó gba agbádá rẹ, má ṣe dá a dúró láti gba ẹ̀wù àwọ̀tẹ́lẹ̀ rẹ pẹ̀lú.
Ame ulenge na areoufi kuwwau kpiliya ghe kunbe, asa umon bollo ugudum fe munu ghe kulutuk fe ku tutun.
30 Sì fi fún gbogbo ẹni tí ó tọrọ lọ́dọ̀ rẹ; lọ́dọ̀ ẹni tí ó sì kó ọ ní ẹrù, má sì ṣe padà béèrè.
Na vat nlenge na atirin fi, asa umon nbollo imomon na idi infe, na uwa tiringhe anifi ba.
31 Gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin sì ti fẹ́ kí ènìyàn ṣe sí yín, kí ẹ̀yin sì ṣe bẹ́ẹ̀ sí wọn pẹ̀lú.
Ile imon na fe idinin su anit sufi fe wang su nani.
32 “Ǹjẹ́ bí ẹ̀yin bá fẹ́ àwọn tí ó fẹ́ yín, ọpẹ́ kí ni ẹ̀yin ní? Àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ pẹ̀lú ń fẹ́ àwọn tí ó fẹ́ wọn.
Asa fe din su usu nalenge na idinin su fere cas, iyaghari uduk fe? Vat inung anan kulapi dinin nsu nalenge na idinin su mine.
33 Bí ẹ̀yin sì ṣoore fún àwọn tí ó ṣoore fún yín, ọpẹ́ kín ni ẹ̀yin ní? Àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ pẹ̀lú ń ṣe bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́.
Asa udin suu imon icine kiti nale na idin su fi imon icine, iyaghari uduk fe? Nanere wang anan kulapi din su we.
34 Bí ẹ̀yin bá fi fún ẹni tí ẹ̀yin ń retí láti rí gbà padà, ọpẹ́ kín ni ẹ̀yin ní? Àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ pẹ̀lú ń yá ẹlẹ́ṣẹ̀, kí wọn lè gba ìwọ̀n bẹ́ẹ̀ padà.
Asa udin yenju iba biufi, iyaghari uduk fe? Inung anan kulapi din nizu ure kiti nalenge na idin yenju iba kpillu ini nani tutun.
35 Ṣùgbọ́n kí ẹ̀yin fẹ́ àwọn ọ̀tá yín kí ẹ sì ṣoore, kí ẹ̀yin sì yá ẹlòmíràn, kí ẹ̀yin má ṣe retí láti rí nǹkan gbà padà; èrè yín yóò sì pọ̀, àwọn ọmọ Ọ̀gá-ògo ni a ó sì máa pè yín: nítorí tí ó ṣe rere fún aláìmoore àti fún ẹni búburú.
Taa usu nnan nivira nin fi, usu ghe gegeme. Niza nani ure na iwa ceo kibinai nworu uba seru ba, uuduk fe ba yitu gbardang, uba so gono nnan kitene kani. Bara ame liti mye din su gegeme kiti nale na idinsu ugodiya ba.
36 Ǹjẹ́ kí ẹ̀yin ní àánú, gẹ́gẹ́ bí Baba yín sì ti ní àánú.
Lanza nkune kune, nafo Ucif fe na adin lanzu nkunekune.
37 “Ẹ má ṣe dá ni lẹ́jọ́, a kì yóò sì dá yín lẹ́jọ́: ẹ má ṣe dá ni lẹ́bi, a kì yóò sì dá yín lẹ́bi: ẹ dáríjì, a ó sì dáríjì yín.
Na uwa ti umon aso unan kulapi ba, bara fe wang iwa su fi nani. Na uwa mollu umon ba. Fewang na iba mollu fi ba, shawa nin kulapi namong, fewang iba shawu nin kunfe.
38 Ẹ fi fún ni, a ó sì fi fún yín; òsùwọ̀n dáradára, àkìmọ́lẹ̀, àti àmìpọ̀, àkúnwọ́sílẹ̀, ni a ó wọ́n si àyà yín: nítorí òsùwọ̀n náà tí ẹ̀yin fi wọ́n, òun ni a ó padà fi wọ́n fún yín.”
Niza anit fewang iba niiti, uni udia na iba zinlinu ukuru ituku bara kuyanga kongo na uguro uman mun, kunere iba guni fe ku mun.”
39 Ó sì pa òwe kan fún wọn wí pé, “Afọ́jú ha lè ṣe amọ̀nà afọ́jú bí? Àwọn méjèèjì kọ́ ni yóò ṣubú sínú ihò bí?
Akuru a belle nani tinan tigoldo. “Unan uduu waansa adursu umon unit uduu libauwa? Asa asu nani vat mine ba diu nanya kuwu, su nani ba?
40 Ẹni tí a ń kọ́ kì í ju olùkọ́ rẹ̀ lọ: ṣùgbọ́n olúkúlùkù ẹni tí a bá kọ dáradára, yóò dàbí olùkọ́ rẹ̀.
Unan nmasu nyinnu nimon wasa akata unan dursuzu mye ba, bara kogha kubi ko na amala umase, aba so nafo unan dursuzu mye.
41 “Èétiṣe tí ìwọ fi ń wo ẹ̀rún igi tí ń bẹ ní ojú arákùnrin rẹ, ṣùgbọ́n ìwọ kò kíyèsi ìtì igi tí ń bẹ ní ojú ara rẹ?
Ani iyaghari nta udin yenju limoo nanya niyizin gwana fine, na idin yenju kukunti na ku di niyizifi ba?
42 Tàbí ìwọ ó ti ṣe lè wí fún arákùnrin rẹ pé, ‘Arákùnrin, jẹ́ kí èmi yọ ẹ̀rún igi tí ń bẹ lójú rẹ,’ nígbà tí ìwọ tìkára rẹ kò kíyèsi ìtì igi tí ń bẹ lójú rẹ? Ìwọ àgàbàgebè, kọ́kọ́ yọ ìtí igi jáde kúrò lójú ara rẹ ná, nígbà náà ni ìwọ ó sì tó ríran gbangba láti yọ èérún igi tí ń bẹ lójú arákùnrin rẹ kúrò.
Iyizirari uba bellu gwana fine, 'Gwana nan nkala limoo longo na lidi nanya niyizi,' fe litife na uyene kukunti na ku di nanya niyizife? Fe unan rusuzu liti! Burno ukala kukunti nanya niyisife, nin nani unin yene gegeme limoo longo na lidi niyizin gwana fine.
43 “Nítorí igi rere kì í so èso búburú; bẹ́ẹ̀ ni igi búburú kì í so èso rere.
Bara na kon kutca kucine wansa anaa kumat kunanzang ba, sa kutca kunanzan nii kumat kucine ba.
44 Olúkúlùkù igi ni a ń fi èso rẹ̀ mọ̀ ọn; nítorí lórí ẹ̀gún òṣùṣú, ènìyàn kì í ká èso ọ̀pọ̀tọ́ bẹ́ẹ̀ ni lórí ẹ̀gún ọ̀gàn a kì í ká èso àjàrà.
Bara ko kuyemu kutca idin kunin bara kumat mere. Bara na anit wasa ikala kupu kidowo fimart ba, nanere iwasa ikala inabi nanya fimart kusho.
45 Ènìyàn rere láti inú yàrá ìṣúra rere ọkàn rẹ̀ ní mú ohun rere jáde wá; àti ènìyàn búburú láti inú ìṣúra búburú ọkàn rẹ̀ ní í mú ohun búburú jáde wá: nítorí láti inú ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ọkàn ní ẹnu ti máa sọ jáde.
Unit ucine nanya nile imon na adin cisu kibinai mye, asa abelle imon ile na idi icine, unan magunta nutuno imon inanzang ile na idi kibinai mye nin nnu mye.
46 “Nítorí náà, èéṣe tí ẹ̀yin ń pè mí ní, ‘Olúwa, Olúwa,’ tí ẹ̀yin kò sì ṣe ohun tí mo wí?
Iyaghari nta idin yicie, 'Cikilari, Cikilari,' nin nani na idin dortu imon ile na nbellen munu ba?
47 Ẹnikẹ́ni tí ó tọ̀ mí wá, tí ó sì ń gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, tí ó sì ń ṣe é, èmi yóò fi ẹni tí ó jọ hàn yín.
Vat ulenge na ada kiti nighe, a lanza tigbulang adofino tinin a di nafo.
48 Ó jọ ọkùnrin kan, tí ó kọ́ ilé, tí ó sì wa ilẹ̀ jìn, tí ó sì fi ìpìlẹ̀ sọlẹ̀ lórí àpáta, nígbà tí kíkún omi sì dé, ìgbì omi kọlu ilé náà, kò sì lè mì ín nítorí tí a fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ sọlẹ̀ lórí àpáta.
Adi nafo unit ule na akee kilari amini nwuzu kiteen anin tuno kutyi ata atata ku. Kubi na uwuru nda kang nmyen nda kilari kane wasa kizillino ba, bara kidinin litino licine.
49 Ṣùgbọ́n ẹni tí ó gbọ́, tí kò sì ṣe é, ó dàbí ọkùnrin tí ó kọ́ ilé sí orí ilẹ̀ láìní ìpìlẹ̀; nígbà tí ìgbì omi kọlù ú, lọ́gán, ó sì wó; wíwó ilé náà sì pọ̀ púpọ̀.”
Bara nani, ulenge na a lanza tigbulang ninghe na adofino tinin ba, aba so nafo unite ulenge na kidiin sa litino licine, aswu uwuru ntolo, nmyen ndofino kilari kane, deddei ki diu, na udiu wa ba caunuu ba.”