< Luke 4 >

1 Jesu sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́, ó padà ti Jordani wá, a sì ti ọwọ́ Ẹ̀mí darí rẹ̀ sí ijù,
تَتَح پَرَں یِیشُح پَوِتْریناتْمَنا پُورْنَح سَنْ یَرْدَّنَنَدْیاح پَراورِتْیاتْمَنا پْرانْتَرَں نِیتَح سَنْ چَتْوارِںشَدِّنانِ یاوَتْ شَیتانا پَرِیکْشِتوبھُوتْ،
2 Ogójì ọjọ́ ni a fi dán an wò lọ́wọ́ èṣù. Kò sì jẹ ohunkóhun ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì: nígbà tí wọ́n sì parí, lẹ́yìn náà ni ebi wá ń pa á.
کِنْچَ تانِ سَرْوَّدِنانِ بھوجَنَں وِنا سْتھِتَتْواتْ کالے پُورْنے سَ کْشُدھِتَوانْ۔
3 Èṣù sì wí fún un pé, “Bí ìwọ bá ṣe Ọmọ Ọlọ́run, pàṣẹ fún òkúta yìí kí ó di àkàrà.”
تَتَح شَیتاناگَتْیَ تَمَوَدَتْ تْوَں چیدِیشْوَرَسْیَ پُتْرَسْتَرْہِ پْرَسْتَرانیتانْ آجْنَیا پُوپانْ کُرُ۔
4 Jesu sì dáhùn, ó wí fún un pé, “A ti kọ̀wé rẹ̀ pé, ‘Ènìyàn kì yóò wà láààyè nípa àkàrà nìkan.’”
تَدا یِیشُرُواچَ، لِپِرِیدرِشِی وِدْیَتے مَنُجَح کیوَلینَ پُوپینَ نَ جِیوَتِ کِنْتْوِیشْوَرَسْیَ سَرْوّابھِراجْنابھِ رْجِیوَتِ۔
5 Lójúkan náà, èṣù sì mú un lọ sí orí òkè gíga, ó sì fi gbogbo ilẹ̀ ọba ayé hàn án.
تَدا شَیتانْ تَمُچَّں پَرْوَّتَں نِیتْوا نِمِشَیکَمَدھْیے جَگَتَح سَرْوَّراجْیانِ دَرْشِتَوانْ۔
6 Èṣù sì wí fún un pé, “Ìwọ ni èmi ó fi gbogbo agbára yìí àti ògo wọn fún: nítorí á sá ti fi fún mi. Ẹnikẹ́ni tí ó bá sì wù mí, èmi a fi í fún.
پَشْچاتْ تَمَوادِیتْ سَرْوَّمْ ایتَدْ وِبھَوَں پْرَتاپَنْچَ تُبھْیَں داسْیامِ تَنْ مَیِ سَمَرْپِتَماسْتے یَں پْرَتِ مَمیچّھا جایَتے تَسْمَے داتُں شَکْنومِ،
7 Ǹjẹ́ bí ìwọ bá foríbalẹ̀ fún mi, gbogbo rẹ̀ ni yóò jẹ́ tìrẹ.”
تْوَں چینْماں بھَجَسے تَرْہِ سَرْوَّمیتَتْ تَوَیوَ بھَوِشْیَتِ۔
8 Jesu sì dáhùn ó sì wí fún un pé, “Kúrò lẹ́yìn mi, Satani, nítorí tí a kọ̀wé rẹ̀ pé, ‘Ìwọ foríbalẹ̀ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ, òun nìkan ṣoṣo ni kí ìwọ kí ó sì máa sìn.’”
تَدا یِیشُسْتَں پْرَتْیُکْتَوانْ دُورِی بھَوَ شَیتانْ لِپِراسْتے، نِجَں پْرَبھُں پَرَمیشْوَرَں بھَجَسْوَ کیوَلَں تَمیوَ سیوَسْوَ چَ۔
9 Èṣù sì mú un lọ sí Jerusalẹmu, ó sì gbé e lé ibi ṣóńṣó tẹmpili, ó sì wí fún un pé, “Bí ìwọ bá ṣe Ọmọ Ọlọ́run, bẹ́ sílẹ̀ fún ara rẹ láti ibí yìí.
اَتھَ شَیتانْ تَں یِرُوشالَمَں نِیتْوا مَنْدِرَسْیَ چُوڈایا اُپَرِ سَمُپَویشْیَ جَگادَ تْوَں چیدِیشْوَرَسْیَ پُتْرَسْتَرْہِ سْتھانادِتو لَمْپھِتْوادھَح
10 A sá ti kọ̀wé rẹ̀ pé, “‘Yóò pàṣẹ fún àwọn angẹli rẹ̀ nítorí rẹ, láti máa ṣe ìtọ́jú rẹ;
پَتَ یَتو لِپِراسْتے، آجْناپَیِشْیَتِ سْوِییانْ دُوتانْ سَ پَرَمیشْوَرَح۔
11 àti pé ní ọwọ́ wọn ni wọn ó gbé ọ sókè, kí ìwọ kí ó má ba à fi ẹsẹ̀ rẹ gbún òkúta.’”
رَکْشِتُں سَرْوَّمارْگے تْواں تینَ تْوَچَّرَنے یَتھا۔ نَ لَگیتْ پْرَسْتَراگھاتَسْتْواں دھَرِشْیَنْتِ تے تَتھا۔
12 Jesu sì dáhùn ó wí fún un pé, “A ti kọ́ pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ dán Olúwa Ọlọ́run rẹ wò.’”
تَدا یِیشُنا پْرَتْیُکْتَمْ اِدَمَپْیُکْتَمَسْتِ تْوَں سْوَپْرَبھُں پَریشَں ما پَرِیکْشَسْوَ۔
13 Nígbà tí èṣù sì parí ìdánwò náà gbogbo, ó fi í sílẹ̀ lọ fun sá à kan.
پَشْچاتْ شَیتانْ سَرْوَّپَرِیکْشاں سَماپْیَ کْشَناتَّں تْیَکْتْوا یَیَو۔
14 Jesu sì fi agbára Ẹ̀mí padà wá sí Galili, òkìkí rẹ̀ sì kàn kálẹ̀ ní gbogbo agbègbè tí ó yí i ká.
تَدا یِیشُراتْمَپْرَبھاواتْ پُنَرْگالِیلْپْرَدیشَں گَتَسْتَدا تَتْسُکھْیاتِشْچَتُرْدِشَں وْیانَشے۔
15 Ó sì ń kọ́ni nínú Sinagọgu wọn; a ń yìn ín lógo láti ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn ènìyàn wá.
سَ تیشاں بھَجَنَگرِہیشُ اُپَدِشْیَ سَرْوَّیح پْرَشَںسِتو بَبھُووَ۔
16 Ó sì wá sí Nasareti, níbi tí a gbé ti tọ́ ọ dàgbà: bí ìṣe rẹ̀ ti rí, ó sì wọ inú Sinagọgu lọ ní ọjọ́ ìsinmi, ó sì dìde láti kàwé.
اَتھَ سَ سْوَپالَنَسْتھانَں ناسَرَتْپُرَمیتْیَ وِشْرامَوارے سْواچارادْ بھَجَنَگیہَں پْرَوِشْیَ پَٹھِتُمُتَّسْتھَو۔
17 A sì fi ìwé wòlíì Isaiah fún un. Nígbà tí ó sì ṣí ìwé náà, ó rí ibi tí a gbé kọ ọ́ pé:
تَتو یِشَیِیَبھَوِشْیَدْوادِنَح پُسْتَکے تَسْیَ کَرَدَتّے سَتِ سَ تَتْ پُسْتَکَں وِسْتارْیَّ یَتْرَ وَکْشْیَمانانِ وَچَنانِ سَنْتِ تَتْ سْتھانَں پْراپْیَ پَپاٹھَ۔
18 “Ẹ̀mí Olúwa ń bẹ lára mi, nítorí tí ó fi àmì òróró yàn mí láti wàásù ìyìnrere fún àwọn òtòṣì. Ó ti rán mi wá láti wàásù ìdásílẹ̀ fún àwọn ìgbèkùn, àti ìmúnríran fún àwọn afọ́jú, àti láti jọ̀wọ́ àwọn tí a pa lára lọ́wọ́,
آتْما تُ پَرَمیشَسْیَ مَدِییوپَرِ وِدْیَتے۔ دَرِدْریشُ سُسَںوادَں وَکْتُں ماں سوبھِشِکْتَوانْ۔ بھَگْنانْتَح کَرَنالّوکانْ سُسْوَسْتھانْ کَرْتُّمیوَ چَ۔ بَنْدِیکرِتیشُ لوکیشُ مُکْتے رْگھوشَیِتُں وَچَح۔ نیتْرانِ داتُمَنْدھیبھْیَسْتْراتُں بَدّھَجَنانَپِ۔
19 láti kéde ọdún ojúrere Olúwa.”
پَریشانُگْرَہے کالَں پْرَچارَیِتُمیوَ چَ۔ سَرْوَّیتَتْکَرَنارْتھایَ مامیوَ پْرَہِنوتِ سَح۔۔
20 Ó sì pa ìwé náà dé, ó fi í fún ìránṣẹ́, ó sì jókòó. Gbogbo àwọn tí ó ń bẹ nínú Sinagọgu sì tẹjúmọ́ ọn.
تَتَح پُسْتَکَں بَدْوّا پَرِچارَکَسْیَ ہَسْتے سَمَرْپْیَ چاسَنے سَمُپَوِشْٹَح، تَتو بھَجَنَگرِہے یاوَنْتو لوکا آسَنْ تے سَرْوّےنَنْیَدرِشْٹْیا تَں وِلُلوکِرے۔
21 Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í wí fún wọn pé, “Lónìí ìwé mímọ́ yìí ṣẹ ní etí yín.”
اَنَنْتَرَمْ اَدْیَیتانِ سَرْوّانِ لِکھِتَوَچَنانِ یُشْماکَں مَدھْیے سِدّھانِ سَ اِماں کَتھاں تیبھْیَح کَتھَیِتُماریبھے۔
22 Gbogbo wọn sì jẹ́rìí rẹ̀, háà sì ṣe wọ́n sí ọ̀rọ̀ oore-ọ̀fẹ́ tí ń jáde ní ẹnu rẹ̀, wọ́n sì wí pé, “Ọmọ Josẹfu kọ́ yìí?”
تَتَح سَرْوّے تَسْمِنْ اَنْوَرَجْیَنْتَ، کِنْچَ تَسْیَ مُکھانِّرْگَتابھِرَنُگْرَہَسْیَ کَتھابھِشْچَمَتْکرِتْیَ کَتھَیاماسُح کِمَیَں یُوشَپھَح پُتْرو نَ؟
23 Jesu sì wí fún wọn pé, “Lóòótọ́ ni ẹ̀yin ó pa òwe yìí sí mi pé, ‘Oníṣègùn, wo ara rẹ̀ sàn! Àwọn ohun tí àwa gbọ́ pé o ti ọwọ́ rẹ ṣe ní Kapernaumu, ṣe é níhìn-ín yìí pẹ̀lú ní ilẹ̀ ara rẹ.’”
تَدا سووادِیدْ ہے چِکِتْسَکَ سْوَمیوَ سْوَسْتھَں کُرُ کَپھَرْناہُومِ یَدْیَتْ کرِتَوانْ تَدَشْرَوشْمَ تاح سَرْواح کْرِیا اَتْرَ سْوَدیشے کُرُ کَتھامیتاں یُویَمیواوَشْیَں ماں وَدِشْیَتھَ۔
24 Ó sì wí pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún un yín, kò sí wòlíì tí a tẹ́wọ́gbà ní ilẹ̀ baba rẹ̀.
پُنَح سووادِیدْ یُشْمانَہَں یَتھارْتھَں وَدامِ، کوپِ بھَوِشْیَدْوادِی سْوَدیشے سَتْکارَں نَ پْراپْنوتِ۔
25 Ṣùgbọ́n mo wí fún un yín nítòótọ́, opó púpọ̀ ni ó wà ní Israẹli nígbà ọjọ́ wòlíì Elijah, nígbà tí ọ̀run fi sé ní ọdún mẹ́ta òun oṣù mẹ́fà, nígbà tí ìyàn ńlá fi mú ká ilẹ̀ gbogbo.
اَپَرَنْچَ یَتھارْتھَں وَچْمِ، ایلِیَسْیَ جِیوَنَکالے یَدا سارْدّھَتْرِتَیَوَرْشانِ یاوَتْ جَلَدَپْرَتِبَنْدھاتْ سَرْوَّسْمِنْ دیشے مَہادُرْبھِکْشَمْ اَجَنِشْٹَ تَدانِیمْ اِسْراییلو دیشَسْیَ مَدھْیے بَہْوْیو وِدھَوا آسَنْ،
26 Kò sì sí ẹnìkan nínú wọn tí a rán Elijah sí, bí kò ṣe sí obìnrin opó kan ní Sarefati, ìlú kan ní Sidoni.
کِنْتُ سِیدونْپْرَدیشِییَسارِپھَتْپُرَنِواسِنِیمْ ایکاں وِدھَواں وِنا کَسْیاشْچِدَپِ سَمِیپے ایلِیَح پْریرِتو نابھُوتْ۔
27 Adẹ́tẹ̀ púpọ̀ ní sì ń bẹ ní Israẹli nígbà wòlíì Eliṣa; kò sì ṣí ọ̀kan nínú wọn tí a wẹ̀nùmọ́, bí kò ṣe Naamani ará Siria.”
اَپَرَنْچَ اِلِیشایَبھَوِشْیَدْوادِوِدْیَمانَتاکالے اِسْراییلْدیشے بَہَوَح کُشْٹھِنَ آسَنْ کِنْتُ سُرِییَدیشِییَں نامانْکُشْٹھِنَں وِنا کوپْیَنْیَح پَرِشْکرِتو نابھُوتْ۔
28 Nígbà tí gbogbo àwọn tí ó wà nínú Sinagọgu gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, inú bi wọ́n gidigidi,
اِماں کَتھاں شْرُتْوا بھَجَنَگیہَسْتھِتا لوکاح سَکْرودھَمْ اُتّھایَ
29 wọ́n sì dìde, wọ́n tì í sóde sí ẹ̀yìn ìlú, wọ́n sì fà á lọ sí bèbè òkè níbi tí wọ́n gbé tẹ ìlú wọn dó, kí wọn bá à lè sọ sílẹ̀ ní ògèdèǹgbé.
نَگَراتَّں بَہِشْکرِتْیَ یَسْیَ شِکھَرِنَ اُپَرِ تیشاں نَگَرَں سْتھاپِتَماسْتے تَسْمانِّکْشیپْتُں تَسْیَ شِکھَرَں تَں نِنْیُح
30 Ṣùgbọ́n ó kọjá láàrín wọn, ó bá tirẹ̀ lọ.
کِنْتُ سَ تیشاں مَدھْیادَپَسرِتْیَ سْتھانانْتَرَں جَگامَ۔
31 Ó sì sọ̀kalẹ̀ wá sí Kapernaumu, ìlú kan ní Galili, ó sì ń kọ́ wọn ní ọjọ́ ìsinmi.
تَتَح پَرَں یِیشُرْگالِیلْپْرَدیشِییَکَپھَرْناہُومْنَگَرَ اُپَسْتھایَ وِشْرامَوارے لوکانُپَدیشْٹُمْ آرَبْدھَوانْ۔
32 Ẹnu sì yà wọ́n sí ẹ̀kọ́ rẹ̀: nítorí tàṣẹtàṣẹ ni ọ̀rọ̀ rẹ̀.
تَدُپَدیشاتْ سَرْوّے چَمَچَّکْرُ رْیَتَسْتَسْیَ کَتھا گُرُتَرا آسَنْ۔
33 Ọkùnrin kan sì wà nínú Sinagọgu, ẹni tí ó ní ẹ̀mí àìmọ́, ó kígbe ní ohùn rara,
تَدانِیں تَدْبھَجَنَگیہَسْتھِتومیدھْیَبھُوتَگْرَسْتَ ایکو جَنَ اُچَّیح کَتھَیاماسَ،
34 “Ó wí pé, kín ni ṣe tàwa tìrẹ, Jesu ará Nasareti? Ìwọ́ wá láti pa wá run bí? Èmí mọ ẹni tí ìwọ í ṣe, Ẹni Mímọ́ Ọlọ́run.”
ہے ناسَرَتِییَیِیشوسْمانْ تْیَجَ، تْوَیا سَہاسْماکَں کَح سَمْبَنْدھَح؟ کِمَسْمانْ وِناشَیِتُمایاسِ؟ تْوَمِیشْوَرَسْیَ پَوِتْرو جَنَ ایتَدَہَں جانامِ۔
35 Jesu sì bá a wí gidigidi, ó wí fun pe, “Pa ẹnu rẹ mọ́, kí o sì jáde lára rẹ̀.” Nígbà tí ẹ̀mí èṣù náà sì gbé e ṣánlẹ̀ ní àwùjọ, ó jáde kúrò lára rẹ̀, kò sì pa á lára.
تَدا یِیشُسْتَں تَرْجَیِتْواوَدَتْ مَونِی بھَوَ اِتو بَہِرْبھَوَ؛ تَتَح سومیدھْیَبھُوتَسْتَں مَدھْیَسْتھانے پاتَیِتْوا کِنْچِدَپْیَہِںسِتْوا تَسْمادْ بَہِرْگَتَوانْ۔
36 Ẹnu sì ya gbogbo wọn, wọ́n sì ń bá ara wọn sọ wí pé, “Irú ẹ̀kọ́ kín ni èyí? Nítorí pẹ̀lú àṣẹ àti agbára ni ó fi bá àwọn ẹ̀mí àìmọ́ wí, wọ́n sì jáde kúrò.”
تَتَح سَرْوّے لوکاشْچَمَتْکرِتْیَ پَرَسْپَرَں وَکْتُماریبھِرے کویَں چَمَتْکارَح۔ ایشَ پْرَبھاوینَ پَراکْرَمینَ چامیدھْیَبھُوتانْ آجْناپَیَتِ تینَیوَ تے بَہِرْگَچّھَنْتِ۔
37 Òkìkí rẹ̀ sì kàn níbi gbogbo ní agbègbè ilẹ̀ náà yíká.
اَنَنْتَرَں چَتُرْدِکْسْتھَدیشانْ تَسْیَ سُکھْیاتِرْوْیاپْنوتْ۔
38 Nígbà tí ó sì dìde kúrò nínú Sinagọgu, ó sì wọ̀ ilé Simoni lọ; ibà sì ti dá ìyá ìyàwó Simoni dùbúlẹ̀, wọ́n sì bẹ̀ ẹ́ nítorí rẹ̀.
تَدَنَنْتَرَں سَ بھَجَنَگیہادْ بَہِراگَتْیَ شِمونو نِویشَنَں پْرَوِویشَ تَدا تَسْیَ شْوَشْرُورْجْوَریناتْیَنْتَں پِیڈِتاسِیتْ شِشْیاسْتَدَرْتھَں تَسْمِنْ وِنَیَں چَکْرُح۔
39 Ó sì súnmọ́ ọ, ó bá ibà náà wí; ibà sì náà sì fi sílẹ̀. O sì dìde lọ́gán, ó ń ṣe ìránṣẹ́ fún wọn.
تَتَح سَ تَسْیاح سَمِیپے سْتھِتْوا جْوَرَں تَرْجَیاماسَ تینَیوَ تاں جْوَروتْیاکْشِیتْ تَتَح سا تَتْکْشَنَمْ اُتّھایَ تانْ سِشیوے۔
40 Nígbà tí oòrùn sì ń wọ̀, àwọn ènìyàn gbe àwọn aláìsàn, tó ní onírúurú àìsàn wá sọ́dọ̀ Jesu; ó sì fi ọwọ́ lé olúkúlùkù wọn, ó sì mú wọn láradá.
اَتھَ سُورْیّاسْتَکالے سْویشاں یے یے جَنا ناناروگَیح پِیڈِتا آسَنْ لوکاسْتانْ یِیشوح سَمِیپَمْ آنِنْیُح، تَدا سَ ایکَیکَسْیَ گاتْرے کَرَمَرْپَیِتْوا تانَروگانْ چَکارَ۔
41 Àwọn ẹ̀mí èṣù sì jáde lára ẹni púpọ̀ pẹ̀lú, wọ́n ń kígbe, wí pé, “Ìwọ ni Ọmọ Ọlọ́run!” Ó sì ń bá wọn wí kò sì jẹ́ kí wọn kí ó fọhùn, nítorí tí wọ́n mọ̀ pé Òun ni Kristi náà.
تَتو بھُوتا بَہُبھْیو نِرْگَتْیَ چِیتْشَبْدَں کرِتْوا چَ بَبھاشِرے تْوَمِیشْوَرَسْیَ پُتْروبھِشِکْتَتْراتا؛ کِنْتُ سوبھِشِکْتَتْراتیتِ تے وِوِدُریتَسْماتْ کارَناتْ تانْ تَرْجَیِتْوا تَدْوَکْتُں نِشِشیدھَ۔
42 Nígbà tí ilẹ̀ sì mọ́, Jesu sì jáde lọ, ó sì ya ara rẹ̀ sọ́tọ̀. Ìjọ ènìyàn sì ń wá a kiri, wọ́n sì tọ̀ ọ́ wá, wọ́n sì dá a dúró, nítorí kí ó má ba à lọ kúrò lọ́dọ̀ wọn.
اَپَرَنْچَ پْرَبھاتے سَتِ سَ وِجَنَسْتھانَں پْرَتَسْتھے پَشْچاتْ جَناسْتَمَنْوِچّھَنْتَسْتَنِّکَٹَں گَتْوا سْتھانانْتَرَگَمَنارْتھَں تَمَنْوَرُنْدھَنْ۔
43 Ṣùgbọ́n ó sì wí fún wọn pé, “Èmi kò lè ṣàìmá wàásù ìyìnrere ti ìjọba Ọlọ́run fún àwọn ìlú mìíràn pẹ̀lú, nítorí náà ni a sá ṣe rán mi.”
کِنْتُ سَ تانْ جَگادَ، اِیشْوَرِییَراجْیَسْیَ سُسَںوادَں پْرَچارَیِتُمْ اَنْیانِ پُرانْیَپِ مَیا یاتَوْیانِ یَتَسْتَدَرْتھَمیوَ پْریرِتوہَں۔
44 Ó sì ń wàásù nínú Sinagọgu ti Judea.
اَتھَ گالِیلو بھَجَنَگیہیشُ سَ اُپَدِدیشَ۔

< Luke 4 >