< Luke 4 >

1 Jesu sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́, ó padà ti Jordani wá, a sì ti ọwọ́ Ẹ̀mí darí rẹ̀ sí ijù,
Kwathi uJesu egcwele uMoya oNgcwele wabuya evela eJordani, wakhokhelelwa nguMoya enkangala,
2 Ogójì ọjọ́ ni a fi dán an wò lọ́wọ́ èṣù. Kò sì jẹ ohunkóhun ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì: nígbà tí wọ́n sì parí, lẹ́yìn náà ni ebi wá ń pa á.
walingwa ngudiyabhola insuku ezingamatshumi amane. Njalo kadlanga lutho ngalezonsuku; kwathi seziphelile, ekucineni walamba.
3 Èṣù sì wí fún un pé, “Bí ìwọ bá ṣe Ọmọ Ọlọ́run, pàṣẹ fún òkúta yìí kí ó di àkàrà.”
Udiyabhola wasesithi kuye: Uba uyiNdodana kaNkulunkulu, tshono kulelilitshe ukuthi libe yisinkwa.
4 Jesu sì dáhùn, ó wí fún un pé, “A ti kọ̀wé rẹ̀ pé, ‘Ènìyàn kì yóò wà láààyè nípa àkàrà nìkan.’”
UJesu wasemphendula, wathi: Kulotshiwe, ukuthi umuntu kayikuphila ngesinkwa sodwa, kodwa ngalo lonke ilizwi likaNkulunkulu.
5 Lójúkan náà, èṣù sì mú un lọ sí orí òkè gíga, ó sì fi gbogbo ilẹ̀ ọba ayé hàn án.
Udiyabhola wasemkhokhelela entabeni ende wamtshengisa yonke imibuso yomhlaba ngesikhatshana.
6 Èṣù sì wí fún un pé, “Ìwọ ni èmi ó fi gbogbo agbára yìí àti ògo wọn fún: nítorí á sá ti fi fún mi. Ẹnikẹ́ni tí ó bá sì wù mí, èmi a fi í fún.
Udiyabhola wasesithi kuye: Amandla wonke la lobukhosi bayo ngizakunika; ngoba anikwe mina, njalo ngiwanika loba ngubani engithandayo.
7 Ǹjẹ́ bí ìwọ bá foríbalẹ̀ fún mi, gbogbo rẹ̀ ni yóò jẹ́ tìrẹ.”
Ngakho wena uba ukhonza phambi kwami, konke kuzakuba ngokwakho.
8 Jesu sì dáhùn ó sì wí fún un pé, “Kúrò lẹ́yìn mi, Satani, nítorí tí a kọ̀wé rẹ̀ pé, ‘Ìwọ foríbalẹ̀ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ, òun nìkan ṣoṣo ni kí ìwọ kí ó sì máa sìn.’”
UJesu wasemphendula wathi: Suka ngemva kwami, Sathane; ngoba kulotshiwe ukuthi: Uzakhothamela eNkosini uNkulunkulu wakho, njalo umkhonze yena yedwa.
9 Èṣù sì mú un lọ sí Jerusalẹmu, ó sì gbé e lé ibi ṣóńṣó tẹmpili, ó sì wí fún un pé, “Bí ìwọ bá ṣe Ọmọ Ọlọ́run, bẹ́ sílẹ̀ fún ara rẹ láti ibí yìí.
Wasemkhokhelela eJerusalema, wammisa engqongeni yethempeli, wasesithi kuye: Uba uyiNdodana kaNkulunkulu, ziwisele phansi usuka lapha;
10 A sá ti kọ̀wé rẹ̀ pé, “‘Yóò pàṣẹ fún àwọn angẹli rẹ̀ nítorí rẹ, láti máa ṣe ìtọ́jú rẹ;
ngoba kulotshiwe ukuthi: Uzalaya ingilosi zakhe ngawe, ukukulondoloza;
11 àti pé ní ọwọ́ wọn ni wọn ó gbé ọ sókè, kí ìwọ kí ó má ba à fi ẹsẹ̀ rẹ gbún òkúta.’”
lokuthi: Zizakuphatha ngezandla, hlezi loba nini ukhube unyawo lwakho elitsheni.
12 Jesu sì dáhùn ó wí fún un pé, “A ti kọ́ pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ dán Olúwa Ọlọ́run rẹ wò.’”
UJesu wasephendula wathi kuye: Kuthiwa: Ungayilingi iNkosi uNkulunkulu wakho.
13 Nígbà tí èṣù sì parí ìdánwò náà gbogbo, ó fi í sílẹ̀ lọ fun sá à kan.
Udiyabhola eseqedile ukulinga konke, wasuka kuye kwaze kwaba ngesinye isikhathi.
14 Jesu sì fi agbára Ẹ̀mí padà wá sí Galili, òkìkí rẹ̀ sì kàn kálẹ̀ ní gbogbo agbègbè tí ó yí i ká.
UJesu wasebuyela eGalili ngamandla kaMoya; lendumela yakhe yaphuma kuso sonke isigaba esizingelezeleyo.
15 Ó sì ń kọ́ni nínú Sinagọgu wọn; a ń yìn ín lógo láti ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn ènìyàn wá.
Yena wasefundisa emasinagogeni abo, edunyiswa yibo bonke.
16 Ó sì wá sí Nasareti, níbi tí a gbé ti tọ́ ọ dàgbà: bí ìṣe rẹ̀ ti rí, ó sì wọ inú Sinagọgu lọ ní ọjọ́ ìsinmi, ó sì dìde láti kàwé.
Wasefika eNazaretha, lapho ayondliwe khona; njengokwejwayela kwakhe wasengena esinagogeni ngosuku lwesabatha, wasukuma ukuze afunde.
17 A sì fi ìwé wòlíì Isaiah fún un. Nígbà tí ó sì ṣí ìwé náà, ó rí ibi tí a gbé kọ ọ́ pé:
Wasenikwa ugwalo lomprofethi uIsaya. Waseluvula ugwalo, wayithola indawo okubhalwe kuyo ukuthi:
18 “Ẹ̀mí Olúwa ń bẹ lára mi, nítorí tí ó fi àmì òróró yàn mí láti wàásù ìyìnrere fún àwọn òtòṣì. Ó ti rán mi wá láti wàásù ìdásílẹ̀ fún àwọn ìgbèkùn, àti ìmúnríran fún àwọn afọ́jú, àti láti jọ̀wọ́ àwọn tí a pa lára lọ́wọ́,
UMoya weNkosi uphezu kwami, ngakho ingigcobile ukuthi ngitshumayele ivangeli kubayanga; ingithumile ukusilisa abadabukileyo enhliziyweni; ukumemezela ukukhululwa kwabathunjiweyo, lokubona kwabayiziphofu, ukukhulula ababandezelweyo,
19 láti kéde ọdún ojúrere Olúwa.”
ukumemezela umnyaka womusa weNkosi.
20 Ó sì pa ìwé náà dé, ó fi í fún ìránṣẹ́, ó sì jókòó. Gbogbo àwọn tí ó ń bẹ nínú Sinagọgu sì tẹjúmọ́ ọn.
Waselugoqa ugwalo, walubuyisela encekwini, wahlala phansi; lamehlo abo bonke ababesesinagogeni amjolozela.
21 Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í wí fún wọn pé, “Lónìí ìwé mímọ́ yìí ṣẹ ní etí yín.”
Waseqala ukuthi kubo: Lamuhla lumbhalo ugcwalisekile endlebeni zenu.
22 Gbogbo wọn sì jẹ́rìí rẹ̀, háà sì ṣe wọ́n sí ọ̀rọ̀ oore-ọ̀fẹ́ tí ń jáde ní ẹnu rẹ̀, wọ́n sì wí pé, “Ọmọ Josẹfu kọ́ yìí?”
Labo bonke bafakaza ngaye, bamangala ngamazwi omusa aphuma emlonyeni wakhe, basebesithi: Lo kayisiyo indodana kaJosefa yini?
23 Jesu sì wí fún wọn pé, “Lóòótọ́ ni ẹ̀yin ó pa òwe yìí sí mi pé, ‘Oníṣègùn, wo ara rẹ̀ sàn! Àwọn ohun tí àwa gbọ́ pé o ti ọwọ́ rẹ ṣe ní Kapernaumu, ṣe é níhìn-ín yìí pẹ̀lú ní ilẹ̀ ara rẹ.’”
Wasesithi kubo: Isibili lizakutsho kimi lesisaga: Melaphi, zelaphe wena; konke lokho esikuzwileyo okwenzeke eKapenawume, kwenze lalapha emzini wakini.
24 Ó sì wí pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún un yín, kò sí wòlíì tí a tẹ́wọ́gbà ní ilẹ̀ baba rẹ̀.
Wathi-ke: Ngiqinisile ngithi kini: Kakho umprofethi owemukelekayo elizweni lakibo.
25 Ṣùgbọ́n mo wí fún un yín nítòótọ́, opó púpọ̀ ni ó wà ní Israẹli nígbà ọjọ́ wòlíì Elijah, nígbà tí ọ̀run fi sé ní ọdún mẹ́ta òun oṣù mẹ́fà, nígbà tí ìyàn ńlá fi mú ká ilẹ̀ gbogbo.
Kodwa ngeqiniso ngithi kini: Abafelokazi abanengi babekhona koIsrayeli ensukwini zikaElija, lapho izulu lalivalekile iminyaka emithathu lenyanga eziyisithupha, kwaze kwaba khona indlala enkulu emhlabeni wonke;
26 Kò sì sí ẹnìkan nínú wọn tí a rán Elijah sí, bí kò ṣe sí obìnrin opó kan ní Sarefati, ìlú kan ní Sidoni.
kodwa uElija kathunyelwanga lakomunye wabo, ngaphandle kweSarepita yeSidoni kowesifazana ongumfelokazi.
27 Adẹ́tẹ̀ púpọ̀ ní sì ń bẹ ní Israẹli nígbà wòlíì Eliṣa; kò sì ṣí ọ̀kan nínú wọn tí a wẹ̀nùmọ́, bí kò ṣe Naamani ará Siria.”
Futhi amalephero amanengi ayekhona koIsrayeli ngesikhathi sikaElisha umprofethi; kodwa kakuhlanjululwanga lamunye wawo, ngaphandle kukaNamani umSiriya.
28 Nígbà tí gbogbo àwọn tí ó wà nínú Sinagọgu gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, inú bi wọ́n gidigidi,
Kwathi bonke ababesesinagogeni bagcwala ulaka, bezizwa lezizinto,
29 wọ́n sì dìde, wọ́n tì í sóde sí ẹ̀yìn ìlú, wọ́n sì fà á lọ sí bèbè òkè níbi tí wọ́n gbé tẹ ìlú wọn dó, kí wọn bá à lè sọ sílẹ̀ ní ògèdèǹgbé.
basebesukuma, bamkhuphela ngaphandle komuzi, bamqhubela eliweni lentaba umuzi wabo owawakhiwe phezu kwayo, ukuze bamphosele phansi eliweni.
30 Ṣùgbọ́n ó kọjá láàrín wọn, ó bá tirẹ̀ lọ.
Kodwa yena edabula phakathi kwabo wahamba.
31 Ó sì sọ̀kalẹ̀ wá sí Kapernaumu, ìlú kan ní Galili, ó sì ń kọ́ wọn ní ọjọ́ ìsinmi.
Wasesehlela eKapenawume umuzi weGalili; njalo wayebafundisa ngamasabatha.
32 Ẹnu sì yà wọ́n sí ẹ̀kọ́ rẹ̀: nítorí tàṣẹtàṣẹ ni ọ̀rọ̀ rẹ̀.
Basebebabaza ngemfundiso yakhe, ngoba ilizwi lakhe lalilamandla.
33 Ọkùnrin kan sì wà nínú Sinagọgu, ẹni tí ó ní ẹ̀mí àìmọ́, ó kígbe ní ohùn rara,
Futhi kwakukhona esinagogeni umuntu owayelomoya wedimoni ongcolileyo, wasememeza ngelizwi elikhulu,
34 “Ó wí pé, kín ni ṣe tàwa tìrẹ, Jesu ará Nasareti? Ìwọ́ wá láti pa wá run bí? Èmí mọ ẹni tí ìwọ í ṣe, Ẹni Mímọ́ Ọlọ́run.”
wathi: Yekela! Silani lawe, Jesu mNazaretha? Uze ukusibhubhisa yini? Ngiyakwazi wena ukuthi ungubani: ONgcwele kaNkulunkulu.
35 Jesu sì bá a wí gidigidi, ó wí fun pe, “Pa ẹnu rẹ mọ́, kí o sì jáde lára rẹ̀.” Nígbà tí ẹ̀mí èṣù náà sì gbé e ṣánlẹ̀ ní àwùjọ, ó jáde kúrò lára rẹ̀, kò sì pa á lára.
UJesu wasemkhuza, esithi: Thula, uphume kuye! Ledimoni selimwisele phakathi laphuma kuye, lingamlimazanga.
36 Ẹnu sì ya gbogbo wọn, wọ́n sì ń bá ara wọn sọ wí pé, “Irú ẹ̀kọ́ kín ni èyí? Nítorí pẹ̀lú àṣẹ àti agbára ni ó fi bá àwọn ẹ̀mí àìmọ́ wí, wọ́n sì jáde kúrò.”
Kwasekubafikela bonke ukumangala, bakhulumisana, besithi: Yilizwi bani leli, ukuthi ngegunya langamandla uyalaya omoya abangcolileyo, baphume?
37 Òkìkí rẹ̀ sì kàn níbi gbogbo ní agbègbè ilẹ̀ náà yíká.
Yasiphuma indumela yakhe kuyo yonke indawo yesigaba esizingelezeleyo.
38 Nígbà tí ó sì dìde kúrò nínú Sinagọgu, ó sì wọ̀ ilé Simoni lọ; ibà sì ti dá ìyá ìyàwó Simoni dùbúlẹ̀, wọ́n sì bẹ̀ ẹ́ nítorí rẹ̀.
Wasesukuma waphuma esinagogeni, wayangena endlini kaSimoni; njalo uninazala kaSimoni wayebanjwe luqhuqho olukhulu; basebemcelela kuye.
39 Ó sì súnmọ́ ọ, ó bá ibà náà wí; ibà sì náà sì fi sílẹ̀. O sì dìde lọ́gán, ó ń ṣe ìránṣẹ́ fún wọn.
Wasemengama, wakhuza uqhuqho, khona lwamyekela; njalo wahle wasukuma wabasebenzela.
40 Nígbà tí oòrùn sì ń wọ̀, àwọn ènìyàn gbe àwọn aláìsàn, tó ní onírúurú àìsàn wá sọ́dọ̀ Jesu; ó sì fi ọwọ́ lé olúkúlùkù wọn, ó sì mú wọn láradá.
Kwathi ekutshoneni kwelanga, bonke ababelababegula izifo ezitshiyeneyo babaletha kuye; wasebeka izandla kulowo lalowo wabo wabasilisa.
41 Àwọn ẹ̀mí èṣù sì jáde lára ẹni púpọ̀ pẹ̀lú, wọ́n ń kígbe, wí pé, “Ìwọ ni Ọmọ Ọlọ́run!” Ó sì ń bá wọn wí kò sì jẹ́ kí wọn kí ó fọhùn, nítorí tí wọ́n mọ̀ pé Òun ni Kristi náà.
Kwasekuphuma lamadimoni kwabanengi, ememeza esithi: Wena unguKristu iNdodana kaNkulunkulu. Wasewakhuza engawavumeli ukuthi akhulume, ngoba ayemazi ukuthi unguKristu.
42 Nígbà tí ilẹ̀ sì mọ́, Jesu sì jáde lọ, ó sì ya ara rẹ̀ sọ́tọ̀. Ìjọ ènìyàn sì ń wá a kiri, wọ́n sì tọ̀ ọ́ wá, wọ́n sì dá a dúró, nítorí kí ó má ba à lọ kúrò lọ́dọ̀ wọn.
Kwathi sekusile, waphuma waya endaweni eyinkangala, lamaxuku amdinga, eza kuye, amvimbela ukuthi angasuki kiwo.
43 Ṣùgbọ́n ó sì wí fún wọn pé, “Èmi kò lè ṣàìmá wàásù ìyìnrere ti ìjọba Ọlọ́run fún àwọn ìlú mìíràn pẹ̀lú, nítorí náà ni a sá ṣe rán mi.”
Kodwa wathi kuwo: Ngimele ukutshumayela ivangeli lombuso kaNkulunkulu lakweminye imizi; ngoba ngithunyelwe lokho.
44 Ó sì ń wàásù nínú Sinagọgu ti Judea.
Wayesetshumayela emasinagogeni eGalili.

< Luke 4 >