< Luke 3 >
1 Ní ọdún kẹ́ẹ̀dógún ìjọba Tiberiu Kesari, nígbà tí Pọntiu Pilatu jẹ́ baálẹ̀ Judea, tí Herodu sì jẹ́ tetrarki Galili, Filipi arákùnrin rẹ̀ sì jẹ́ tetrarki Iturea àti ti Trakoniti, Lisania sì jẹ́ tetrarki Abilene,
A roku piętnastego panowania Tyberyjusza Cesarza, gdy Poncki Piłat był starostą Judzkim, a Herod Tetrarchą Galilejskim, a Filip, brat jego, Tetrarchą Iturejskim i krainy Trachonickiej, a Lizanijasz Tetrarchą Abileńskim,
2 tí Annasi òun Kaiafa ń ṣe olórí àwọn àlùfáà, nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tọ Johanu ọmọ Sekariah wá ní ijù.
Za najwyższych kapłanów Annasza i Kaifasza, stało się słowo Boże do Jana, Zacharyjaszowego syna, na puszczy.
3 Ó sì wá sí gbogbo ilẹ̀ aginjù Jordani, ó ń wàásù ìtẹ̀bọmi ìrònúpìwàdà fún ìmúkúrò ẹ̀ṣẹ̀,
I przyszedł do wszystkiej krainy leżącej około Jordanu, każąc chrzest pokuty na odpuszczenie grzechów.
4 bí a ti kọ ọ́ nínú ìwé ọ̀rọ̀ wòlíì Isaiah pé, “Ohùn ẹni tí ń kígbe ní ijù, ‘Ẹ tún ọ̀nà Olúwa ṣe, ẹ mú ipa ọ̀nà rẹ̀ tọ́.
Jako napisano w księgach proroctw Izajasza proroka, mówiącego: Głos wołającego na puszczy; gotujcie drogę Pańską, proste czyńcie ścieżki jego.
5 Gbogbo ọ̀gbun ni a yóò kún, gbogbo òkè ńlá àti òkè kékeré ni a ó tẹ́ pẹẹrẹ. Wíwọ́ ni a ó ṣe ní títọ́, àti ọ̀nà gbọ́ngungbọ̀ngun ni a o sọ di dídán.
Każdy padół będzie wypełniony, a każda góra i pagórek będzie zniżony, i miejsca krzywe wyprostują się, a ostre drogi będą gładkiemi;
6 Gbogbo ènìyàn ni yóò sì rí ìgbàlà Ọlọ́run.’”
I ogląda wszelkie ciało zbawienie Boże.
7 Nígbà náà ni ó wí fún ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn tí ó wá láti ṣe ìtẹ̀bọmi lọ́dọ̀ rẹ̀ pé, “Ẹ̀yin ìran paramọ́lẹ̀, ta ni ó kìlọ̀ fún un yín láti sá kúrò nínú ìbínú tí ń bọ̀?
Mówił tedy ludowi, który wychodził, aby był ochrzczony od niego: Rodzaju jaszczurczy! któż wam pokazał, żebyście uciekali przed przyszłym gniewem?
8 Nítorí náà kí ẹ̀yin kí ó so èso tí ó yẹ fún ìrònúpìwàdà, kí ẹ má sì ṣe sí í wí nínú ara yín pé, ‘Àwa ní Abrahamu ní baba.’ Kí èmi kí ó wí fún un yín, Ọlọ́run lè gbé ọmọ dìde fún Abrahamu nínú òkúta wọ̀nyí.
Przynoścież tedy owoce godne pokuty, a nie poczynajcie mówić sami w sobie: Ojca mamy Abrahama; albowiem powiadam wam, że Bóg może i z tych kamieni wzbudzić dzieci Abrahamowi.
9 Àti nísinsin yìí pẹ̀lú, a fi àáké lé gbòǹgbò igi náà, gbogbo igi tí kò bá so èso rere, a óò ge lulẹ̀, a sì wọ jù sínú iná.”
A już siekiera do korzenia drzew przyłożona jest; przetoż każde drzewo, które nie przynosi owocu dobrego, bywa wycięte i w ogień wrzucone.
10 Àwọn ènìyàn sì ń bi í pé, “Kí ni kí àwa kí ó ṣe?”
I pytał go lud mówiąc: Cóż tedy czynić będziemy?
11 Ó dáhùn ó sì wí fún wọn pé, “Ẹni tí ó bá ní ẹ̀wù méjì, kí ó fi ọ̀kan fún ẹni tí kò ní; ẹni tí ó bá sì ní oúnjẹ, kí ó ṣe bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú.”
A on odpowiadając rzekł im: Kto ma dwie suknie, niechaj udzieli temu, co nie ma; a kto ma pokarm niech także uczyni.
12 Àwọn agbowó òde sì tọ̀ ọ́ wá láti ṣe ìtẹ̀bọmi lọ́dọ̀ rẹ̀, wọ́n sì bi í pé, “Olùkọ́, kí ni àwa ó ha ṣe?”
Przyszli też i celnicy, aby byli chrzczeni, i rzekli do niego: Nauczycielu! a my cóż czynić będziemy?
13 Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ má ṣe fi agbára gbà jù bí a ti rán yín lọ mọ́.”
A on rzekł do nich: Nic więcej nie wyciągajcie nad to, co wam postanowiono.
14 Àwọn ọmọ-ogun sì béèrè lọ́dọ̀ rẹ̀ pé, “Àti àwa, kí ni àwa ó ṣe?” Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ má ṣe hùwà ipá sí ẹnikẹ́ni, kí ẹ má sì ṣe ka ẹ̀sùn èké sí ẹnikẹ́ni; kí òwò ọ̀yà yín tó yín.”
Pytali go też i żołnierze, mówiąc: A my cóż czynić będziemy? I rzekł do nich: Nikomu gwałtu nie czyńcie, i nikogo nie potwarzajcie, a przestawajcie na żołdzie waszym.
15 Bí àwọn ènìyàn sì ti ń retí, tí gbogbo wọn sì ń rò nínú ara wọn nítorí Johanu, bí òun ni Kristi tàbí òun kọ́;
A gdy lud oczekiwał, i myślili wszyscy w sercach swych o Janie, jeśliby snać on nie był Chrystusem,
16 Johanu dáhùn ó sì wí fún gbogbo wọn pé, “Lóòótọ́ ni èmi ń fi omi bamitiisi yín, ṣùgbọ́n ẹni tí ó lágbára jù mí lọ ń bọ̀, okùn bàtà ẹsẹ̀ ẹni tí èmi kò tó tú, Òun ni yóò fi Ẹ̀mí Mímọ́ àti iná bamitiisi yín.
Odpowiedział Jan wszystkim, mówiąc: Jać was chrzczę wodą; lecz idzie mocniejszy nad mię, któremum nie jest godzien rozwiązać rzemyka u butów jego; ten was chrzcić będzie Duchem Świętym i ogniem.
17 Ẹni tí àtẹ rẹ̀ ń bẹ ní ọwọ́ rẹ̀, láti gbá ilẹ̀ ìpakà rẹ̀ mọ́ tó tó, kí ó sì kó alikama rẹ̀ sínú àká; ṣùgbọ́n ìyàngbò ni yóò fi iná àjóòkú sun.”
Którego łopata jest w ręku jego, a wyczyści bojewisko swoje, i zgromadzi pszenicę do gumna swego, ale plewy spali ogniem nieugaszonym.
18 Johanu lo oríṣìíríṣìí ọ̀rọ̀ púpọ̀ láti gba àwọn ènìyàn níyànjú àti láti wàásù ìyìnrere fún wọn.
A tak wiele i innych rzeczy napominając, odpowiadał ludowi.
19 Ṣùgbọ́n nígbà ti Johanu bú Herodu tetrarki, tí ó bá wí nítorí Herodia aya Filipi arákùnrin rẹ̀, àti nítorí ohun búburú gbogbo tí Herodu tí ṣe,
A Herod Tetrarcha, będąc strofowany od niego dla Herodyjady, żony Filipa, brata jego, i dla wszystkich złych spraw, które czynił Herod.
20 Ó fi èyí parí gbogbo rẹ̀ nígbà tí ó fi Johanu sínú túbú.
Przydał i to nade wszystko, iż wsadził Jana do więzienia.
21 Nígbà tí a ṣe ìtẹ̀bọmi àwọn ènìyàn gbogbo tán, ó sì ṣe, a bamitiisi Jesu pẹ̀lú, bí ó ti ń gbàdúrà, ọ̀run ṣí sílẹ̀,
I stało się, gdy był ochrzczony wszystek lud, i gdy Jezus był ochrzczony, i modlił się, że się niebo otworzyło;
22 Ẹ̀mí Mímọ́ sì sọ̀kalẹ̀ sí orí rẹ̀ ní àwọ̀ àdàbà, ohùn kan sì ti ọ̀run wá, tí ó wí pé, “Ìwọ ni àyànfẹ́ ọmọ mi; ẹni tí inú mi dùn sí gidigidi.”
I zstąpił nań Duch Święty w kształcie cielesnym jako gołębica, i stał się głos z nieba, mówiąc: Tyś jest on Syn mój miły; w tobie mi się upodobało.
23 Jesu tìkára rẹ̀ ń tó bí ẹni ọgbọ̀n ọdún, nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ ìránṣẹ́ rẹ̀ ó jẹ́ (bí a ti fi pè) ọmọ Josẹfu, tí í ṣe ọmọ Eli,
A Jezus poczynał być jakoby w trzydziestu latach, będąc (jako mniemano, ) synem Józefa, syna Helego,
24 tí í ṣe ọmọ Mattati, tí í ṣe ọmọ Lefi, tí í ṣe ọmọ Meliki, tí í ṣe ọmọ Janai, tí í ṣe ọmọ Josẹfu,
Syna Matatowego, syna Lewiego, syna Melchyjego, syna Jannego, syna Józefowego,
25 tí í ṣe ọmọ Mattatia, tí í ṣe ọmọ Amosi, tí í ṣe ọmọ Naumu, tí í ṣe ọmọ Esili, tí í ṣe ọmọ Nagai,
Syna Matatyjaszowego, syna Amosowego, syna Naumowego, syna Eslego, syna Naggiego,
26 tí í ṣe ọmọ Maati, tí í ṣe ọmọ Mattatia, tí í ṣe ọmọ Ṣimei, tí í ṣe ọmọ Josẹfu, tí í ṣe ọmọ Joda,
Syna Maatowego, syna Mattatyjaszowego, syna Semejego, syna Józefowego, syna Judowego,
27 tí í ṣe ọmọ Joana, tí í ṣe ọmọ Resa, tí í ṣe ọmọ Serubbabeli, tí í ṣe ọmọ Ṣealitieli, tí í ṣe ọmọ Neri,
Syna Joannowego, syna Resowego, syna Zorobabelowego, syna Salatyjelowego, syna Neryjego,
28 tí í ṣe ọmọ Meliki, tí í ṣe ọmọ Adi, tí í ṣe ọmọ Kosamu, tí í ṣe ọmọ Elmadamu, tí í ṣe ọmọ Eri,
Syna Melchyjego, syna Addyjego, syna Kosamowego, syna Elmodamowego, syna Irowego,
29 tí í ṣe ọmọ Joṣua, tí í ṣe ọmọ Elieseri, tí í ṣe ọmọ Jorimu, tí í ṣe Mattati, tí í ṣe ọmọ Lefi,
Syna Jozego, syna Elijezerowego, syna Jorymowego, syna Mattatego, syna Lewiego,
30 tí í ṣe ọmọ Simeoni, tí í ṣe ọmọ Juda, tí í ṣe ọmọ Josẹfu, tí í ṣe ọmọ Jonamu, tí í ṣe ọmọ Eliakimu,
Syna Symeonowego, syna Judowego, syna Józefowego, syna Jonanowego, syna Elijakimowego,
31 tí í ṣe ọmọ Melea, tí í ṣe ọmọ Menna, tí í ṣe ọmọ Mattata, tí í ṣe ọmọ Natani, tí í ṣe ọmọ Dafidi,
Syna Meleowego, syna Mainanowego, syna Mattatanowego, syna Natanowego, syna Dawidowego,
32 tí í ṣe ọmọ Jese, tí í ṣe ọmọ Obedi, tí í ṣe ọmọ Boasi, tí í ṣe ọmọ Salmoni, tí í ṣe ọmọ Nahiṣoni,
Syna Jessego, syna Obedowego, syna Boozowego, syna Salmonowego, syna Nasonowego,
33 tí í ṣe ọmọ Amminadabu, tí í ṣe ọmọ Ramu, tí í ṣe ọmọ Hesroni, tí í ṣe ọmọ Peresi, tí í ṣe ọmọ Juda.
Syna Aminadabowego, syna Aramowego, syna Esromowego, syna Faresowego, syna Judowego,
34 Tí í ṣe ọmọ Jakọbu, tí í ṣe ọmọ Isaaki, tí í ṣe ọmọ Abrahamu, tí í ṣe ọmọ Tẹra, tí í ṣe ọmọ Nahori,
Syna Jakóbowego, syna Izaakowego, syna Abrahamowego, syna Tarego, syna Nachorowego,
35 tí í ṣe ọmọ Serugu, tí í ṣe ọmọ Reu, tí í ṣe ọmọ Pelegi, tí í ṣe ọmọ Eberi, tí í ṣe ọmọ Ṣela.
Syna Saruchowego, syna Ragawowego, syna Falekowego, syna Heberowego, syna Salego,
36 Tí í ṣe ọmọ Kainani, tí í ṣe ọmọ Arfaksadi, tí í ṣe ọmọ Ṣemu, tí í ṣe ọmọ Noa, tí í ṣe ọmọ Lameki,
Syna Kainowego, syna Arfaksadowego, syna Semowego, syna Noego, syna Lamechowego,
37 tí í ṣe ọmọ Metusela, tí í ṣe ọmọ Enoku, tí í ṣe ọmọ Jaredi, tí í ṣe ọmọ Mahalaleli, tí í ṣe ọmọ Kainani.
Syna Matusalemowego, syna Enochowego, syna Jaredowego, syna Malaleelowego, syna Kainanowego,
38 Tí í ṣe ọmọ Enosi, tí í ṣe ọmọ Seti, tí í ṣe ọmọ Adamu, tí í ṣe ọmọ Ọlọ́run.
Syna Enosowego, syna Setowego, syna Adamowego, syna Bożego.