< Luke 24 >
1 Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ ọ̀sẹ̀, àwọn obìnrin wá sí ibojì, wọ́n sì mú ìkunra olóòórùn dídùn ti wọ́n tí pèsè sílẹ̀ wá.
atha saptāhaprathamadinē'tipratyūṣē tā yōṣitaḥ sampāditaṁ sugandhidravyaṁ gr̥hītvā tadanyābhiḥ kiyatībhiḥ strībhiḥ saha śmaśānaṁ yayuḥ|
2 Òkúta ti yí kúrò ní ẹnu ibojì.
kintu śmaśānadvārāt pāṣāṇamapasāritaṁ dr̥ṣṭvā
3 Nígbà tí wọ́n sì wọ inú rẹ̀, wọn kò rí òkú Jesu Olúwa.
tāḥ praviśya prabhō rdēhamaprāpya
4 Bí wọ́n ti dààmú kiri níhà ibẹ̀, kíyèsi i, àwọn ọkùnrin méjì aláṣọ dídán dúró tì wọ́n.
vyākulā bhavanti ētarhi tējōmayavastrānvitau dvau puruṣau tāsāṁ samīpē samupasthitau
5 Nígbà tí ẹ̀rù ń bà wọ́n, tí wọ́n sì dojúbolẹ̀, àwọn angẹli náà bi wọ́n pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń wá alààyè láàrín àwọn òkú?
tasmāttāḥ śaṅkāyuktā bhūmāvadhōmukhyasyasthuḥ| tadā tau tā ūcatu rmr̥tānāṁ madhyē jīvantaṁ kutō mr̥gayatha?
6 Kò sí níhìn-ín yìí, ṣùgbọ́n ó jíǹde; ẹ rántí bí ó ti wí fún yín nígbà tí ó wà ní Galili.
sōtra nāsti sa udasthāt|
7 Pé, ‘A ó fi Ọmọ Ènìyàn lé àwọn ènìyàn ẹlẹ́ṣẹ̀ lọ́wọ́, a ó sì kàn án mọ́ àgbélébùú, ní ọjọ́ kẹta yóò sì jíǹde.’”
pāpināṁ karēṣu samarpitēna kruśē hatēna ca manuṣyaputrēṇa tr̥tīyadivasē śmaśānādutthātavyam iti kathāṁ sa galīli tiṣṭhan yuṣmabhyaṁ kathitavān tāṁ smarata|
8 Wọ́n sì rántí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
tadā tasya sā kathā tāsāṁ manaḥsu jātā|
9 Wọ́n sì padà ti ibojì wá, wọ́n sì ròyìn gbogbo nǹkan wọ̀nyí fún àwọn mọ́kànlá, àti fún gbogbo àwọn ìyókù.
anantaraṁ śmaśānād gatvā tā ēkādaśaśiṣyādibhyaḥ sarvvēbhyastāṁ vārttāṁ kathayāmāsuḥ|
10 Maria Magdalene, àti Joanna, àti Maria ìyá Jakọbu, àti àwọn mìíràn pẹ̀lú wọn sì ni àwọn tí ó ròyìn nǹkan wọ̀nyí fún àwọn aposteli.
magdalīnīmariyam, yōhanā, yākūbō mātā mariyam tadanyāḥ saṅginyō yōṣitaśca prēritēbhya ētāḥ sarvvā vārttāḥ kathayāmāsuḥ
11 Ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sì dàbí ìsọkúsọ lójú wọn, wọn kò sì gbà wọ́n gbọ́.
kintu tāsāṁ kathām anarthakākhyānamātraṁ buddhvā kōpi na pratyait|
12 Nígbà náà ni Peteru dìde, ó súré lọ sí ibojì; nígbà tí ó sì bẹ̀rẹ̀, ó rí aṣọ àlà lọ́tọ̀ fúnra wọn, ó sì padà lọ sí ilé rẹ̀, ẹnu yà á sí ohun tí ó ṣe.
tadā pitara utthāya śmaśānāntikaṁ dadhāva, tatra ca prahvō bhūtvā pārśvaikasthāpitaṁ kēvalaṁ vastraṁ dadarśa; tasmādāścaryyaṁ manyamānō yadaghaṭata tanmanasi vicārayan pratasthē|
13 Sì kíyèsi i, àwọn méjì nínú wọn ń lọ ní ọjọ́ náà sí ìletò kan tí a ń pè ní Emmausi, tí ó jìnnà sí Jerusalẹmu níwọ̀n ọgọ́ta ibùsọ̀.
tasminnēva dinē dvau śiyyau yirūśālamaścatuṣkrōśāntaritam immāyugrāmaṁ gacchantau
14 Wọ́n ń bá ara wọn sọ̀rọ̀ gbogbo nǹkan wọ̀nyí tí ó ṣẹlẹ̀.
tāsāṁ ghaṭanānāṁ kathāmakathayatāṁ
15 Ó sì ṣe, bí wọ́n ti ń bá ara wọn sọ̀rọ̀, tí wọ́n sì ń bá ara wọn jíròrò, Jesu tìkára rẹ̀ súnmọ́ wọn, ó sì ń bá wọn rìn lọ.
tayōrālāpavicārayōḥ kālē yīśurāgatya tābhyāṁ saha jagāma
16 Ṣùgbọ́n a rú wọn lójú, kí wọn má le mọ̀ ọ́n.
kintu yathā tau taṁ na paricinutastadarthaṁ tayō rdr̥ṣṭiḥ saṁruddhā|
17 Ó sì bi wọ́n pé, “Ọ̀rọ̀ kín ni ẹ̀yin ń bá ara yín sọ, bí ẹ̀yin ti ń rìn?” Wọ́n sì dúró jẹ́, wọ́n fajúro.
sa tau pr̥ṣṭavān yuvāṁ viṣaṇṇau kiṁ vicārayantau gacchathaḥ?
18 Ọ̀kan nínú wọn, tí a ń pè ní Kileopa, sì dáhùn wí fún un pé, “Àlejò sá à ni ìwọ ní Jerusalẹmu, tí ìwọ kò sì mọ ohun tí ó ṣẹ̀ níbẹ̀ ní ọjọ́ wọ̀nyí?”
tatastayōḥ kliyapānāmā pratyuvāca yirūśālamapurē'dhunā yānyaghaṭanta tvaṁ kēvalavidēśī kiṁ tadvr̥ttāntaṁ na jānāsi?
19 Ó sì bi wọ́n pé, “Kín ni?” Wọ́n sì wí fún un pé, “Ní ti Jesu ti Nasareti, ẹni tí ó jẹ́ wòlíì, tí ó pọ̀ ní ìṣe àti ní ọrọ̀ níwájú Ọlọ́run àti gbogbo ènìyàn,
sa papraccha kā ghaṭanāḥ? tadā tau vaktumārēbhātē yīśunāmā yō nāsaratīyō bhaviṣyadvādī īśvarasya mānuṣāṇāñca sākṣāt vākyē karmmaṇi ca śaktimānāsīt
20 àti bí àwọn olórí àlùfáà àti àwọn alàgbà wa ti fi òun lé wọn lọ́wọ́ láti dá a lẹ́bi ikú, àti bí wọ́n ti kàn án mọ́ àgbélébùú.
tam asmākaṁ pradhānayājakā vicārakāśca kēnāpi prakārēṇa kruśē viddhvā tasya prāṇānanāśayan tadīyā ghaṭanāḥ;
21 Bẹ́ẹ̀ ni òun ni àwa ti ní ìrètí pé, òun ni ìbá dá Israẹli ní ìdè. Àti pẹ̀lú gbogbo nǹkan wọ̀nyí, òní ni ó di ọjọ́ kẹta tí nǹkan wọ̀nyí ti ṣẹlẹ̀.
kintu ya isrāyēlīyalōkān uddhārayiṣyati sa ēvāyam ityāśāsmābhiḥ kr̥tā|tadyathā tathāstu tasyā ghaṭanāyā adya dinatrayaṁ gataṁ|
22 Àwọn obìnrin kan pẹ̀lú nínú ẹgbẹ́ wa, tí wọ́n lọ si ibojì ní kùtùkùtù, sì wá yà wá lẹ́nu,
adhikantvasmākaṁ saṅginīnāṁ kiyatstrīṇāṁ mukhēbhyō'sambhavavākyamidaṁ śrutaṁ;
23 nígbà tí wọn kò sì rí òkú rẹ̀, wọ́n wá wí pé, àwọn rí ìran àwọn angẹli tí wọ́n wí pé, ó wà láààyè.
tāḥ pratyūṣē śmaśānaṁ gatvā tatra tasya dēham aprāpya vyāghuṭyētvā prōktavatyaḥ svargīsadūtau dr̥ṣṭāvasmābhistau cāvādiṣṭāṁ sa jīvitavān|
24 Àti àwọn kan tí wọ́n wà pẹ̀lú wa lọ sí ibojì, wọ́n sì rí i gẹ́gẹ́ bí àwọn obìnrin náà ti wí, ṣùgbọ́n òun tìkára rẹ̀ ni wọn kò rí.”
tatōsmākaṁ kaiścit śmaśānamagamyata tē'pi strīṇāṁ vākyānurūpaṁ dr̥ṣṭavantaḥ kintu taṁ nāpaśyan|
25 Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin tí òye kò yé, tí ẹ sì yigbì ní àyà láti gba gbogbo èyí tí àwọn wòlíì ti wí gbọ́,
tadā sa tāvuvāca, hē abōdhau hē bhaviṣyadvādibhiruktavākyaṁ pratyētuṁ vilambamānau;
26 kò ha yẹ kí Kristi ó jìyà nǹkan wọ̀nyí kí ó sì wọ inú ògo rẹ̀ lọ.”
ētatsarvvaduḥkhaṁ bhuktvā svabhūtiprāptiḥ kiṁ khrīṣṭasya na nyāyyā?
27 Ó sì bẹ̀rẹ̀ láti Mose àti gbogbo àwọn wòlíì wá, ó sì túmọ̀ nǹkan fún wọn nínú ìwé mímọ́ gbogbo nípa ti ara rẹ̀.
tataḥ sa mūsāgranthamārabhya sarvvabhaviṣyadvādināṁ sarvvaśāstrē svasmin likhitākhyānābhiprāyaṁ bōdhayāmāsa|
28 Wọ́n sì súnmọ́ ìletò tí wọ́n ń lọ, ó sì ṣe bí ẹni pé yóò lọ sí iwájú.
atha gamyagrāmābhyarṇaṁ prāpya tēnāgrē gamanalakṣaṇē darśitē
29 Wọ́n sì rọ̀ ọ́, pé, “Bá wa dúró: nítorí ó di ọjọ́ alẹ́, ọjọ́ sì kọjá tán.” Ó sì wọlé lọ, ó bá wọn dúró.
tau sādhayitvāvadatāṁ sahāvābhyāṁ tiṣṭha dinē gatē sati rātrirabhūt; tataḥ sa tābhyāṁ sārddhaṁ sthātuṁ gr̥haṁ yayau|
30 Ó sì ṣe, bí ó ti bá wọn jókòó ti oúnjẹ, ó mú àkàrà, ó súre sí i, ó sì bù ú, ó sì fi fún wọn.
paścādbhōjanōpavēśakālē sa pūpaṁ gr̥hītvā īśvaraguṇān jagāda tañca bhaṁktvā tābhyāṁ dadau|
31 Ojú wọn sì là, wọ́n sì mọ̀ ọ́n, ó sì nù mọ́ wọn ní ojú.
tadā tayō rdr̥ṣṭau prasannāyāṁ taṁ pratyabhijñatuḥ kintu sa tayōḥ sākṣādantardadhē|
32 Wọ́n sì bá ara wọn sọ pé, “Ọkàn wa kò ha gbiná nínú wa, nígbà tí ó ń bá wa sọ̀rọ̀ tí ó sì ń túmọ̀ ìwé mímọ́ fún wa!”
tatastau mithōbhidhātum ārabdhavantau gamanakālē yadā kathāmakathayat śāstrārthañcabōdhayat tadāvayō rbuddhiḥ kiṁ na prājvalat?
33 Wọ́n sì dìde ní wákàtí kan náà, wọ́n padà lọ sí Jerusalẹmu, wọ́n sì bá àwọn mọ́kànlá péjọ, àti àwọn tí ń bẹ lọ́dọ̀ wọn.
tau tatkṣaṇādutthāya yirūśālamapuraṁ pratyāyayatuḥ, tatsthānē śiṣyāṇām ēkādaśānāṁ saṅgināñca darśanaṁ jātaṁ|
34 Wọn si wí pé, “Olúwa jíǹde nítòótọ́, ó sì ti fi ara hàn fún Simoni!”
tē prōcuḥ prabhurudatiṣṭhad iti satyaṁ śimōnē darśanamadācca|
35 Àwọn náà sì ròyìn nǹkan tí ó ṣe ní ọ̀nà, àti bí ó ti di mí mọ̀ fún wọn ní bíbu àkàrà.
tataḥ pathaḥ sarvvaghaṭanāyāḥ pūpabhañjanēna tatparicayasya ca sarvvavr̥ttāntaṁ tau vaktumārēbhātē|
36 Bí wọ́n sì ti ń sọ nǹkan wọ̀nyí Jesu tìkára rẹ̀ dúró láàrín wọn, ó sì wí fún wọn pé, “Àlàáfíà fún yín.”
itthaṁ tē parasparaṁ vadanti tatkālē yīśuḥ svayaṁ tēṣāṁ madhya prōtthaya yuṣmākaṁ kalyāṇaṁ bhūyād ityuvāca,
37 Ṣùgbọ́n àyà fò wọ́n, wọ́n sì wárìrì, wọ́n ṣe bí àwọn rí ẹ̀mí kan.
kintu bhūtaṁ paśyāma ityanumāya tē samudvivijirē trēṣuśca|
38 Ó sì wí fún wọn pé, “Èéṣe tí ara yín kò lélẹ̀? Èé sì ti ṣe tí èròkerò fi ń sọ nínú ọkàn yín?
sa uvāca, kutō duḥkhitā bhavatha? yuṣmākaṁ manaḥsu sandēha udēti ca kutaḥ?
39 Ẹ wo ọwọ́ mi àti ẹsẹ̀ mi, pé èmi tìkára mi ni! Ẹ dì mímú kí ẹ wò ó nítorí tí iwin kò ní ẹran àti egungun lára, bí ẹ̀yin ti rí tí èmi ní.”
ēṣōhaṁ, mama karau paśyata varaṁ spr̥ṣṭvā paśyata, mama yādr̥śāni paśyatha tādr̥śāni bhūtasya māṁsāsthīni na santi|
40 Nígbà tí ó sì wí bẹ́ẹ̀ tan, ó fi ọwọ́ àti ẹsẹ̀ rẹ̀ hàn wọ́n.
ityuktvā sa hastapādān darśayāmāsa|
41 Nígbà tí wọn kò sì tí ì gbàgbọ́ fún ayọ̀, àti fún ìyanu, ó wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ní ohunkóhun jíjẹ níhìn-ín yìí?”
tē'sambhavaṁ jñātvā sānandā na pratyayan| tataḥ sa tān papraccha, atra yuṣmākaṁ samīpē khādyaṁ kiñcidasti?
42 Wọ́n sì fún un ní ẹja tí a fi oyin sè.
tatastē kiyaddagdhamatsyaṁ madhu ca daduḥ
43 Ó sì gbà á, ó jẹ ẹ́ lójú wọn.
sa tadādāya tēṣāṁ sākṣād bubhujē
44 Ó sì wí fún wọn pé, “Wọ̀nyí ni ọ̀rọ̀ tí mo sọ fún yín, nígbà tí èmí ti wà pẹ̀lú yín pé, a ní láti mú ohun gbogbo ṣẹ, tí a ti kọ nínú òfin Mose, àti nínú ìwé àwọn wòlíì, àti nínú Saamu, nípasẹ̀ mi.”
kathayāmāsa ca mūsāvyavasthāyāṁ bhaviṣyadvādināṁ granthēṣu gītapustakē ca mayi yāni sarvvāṇi vacanāni likhitāni tadanurūpāṇi ghaṭiṣyantē yuṣmābhiḥ sārddhaṁ sthitvāhaṁ yadētadvākyam avadaṁ tadidānīṁ pratyakṣamabhūt|
45 Nígbà náà ni ó ṣí wọn ní iyè, kí ìwé mímọ́ lè yé wọn.
atha tēbhyaḥ śāstrabōdhādhikāraṁ datvāvadat,
46 Ó sì wí fún wọn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni a ti kọ̀wé rẹ̀, pé: kí Kristi jìyà, àti kí ó sì jíǹde ní ọjọ́ kẹta kúrò nínú òkú,
khrīṣṭēnētthaṁ mr̥tiyātanā bhōktavyā tr̥tīyadinē ca śmaśānādutthātavyañcēti lipirasti;
47 àti pé kí a wàásù ìrònúpìwàdà àti ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀ lórúkọ rẹ̀, ní orílẹ̀-èdè gbogbo, bẹ̀rẹ̀ láti Jerusalẹmu lọ.
tannāmnā yirūśālamamārabhya sarvvadēśē manaḥparāvarttanasya pāpamōcanasya ca susaṁvādaḥ pracārayitavyaḥ,
48 Ẹ̀yin sì ni ẹlẹ́rìí nǹkan wọ̀nyí.
ēṣu sarvvēṣu yūyaṁ sākṣiṇaḥ|
49 Èmi yóò rán ohun tí Baba mi ṣe ìlérí sí yín, ṣùgbọ́n ẹ jókòó ní ìlú Jerusalẹmu, títí a ó fífi agbára wọ̀ yín, láti òkè ọ̀run wá.”
aparañca paśyata pitrā yat pratijñātaṁ tat prēṣayiṣyāmi, ataēva yāvatkālaṁ yūyaṁ svargīyāṁ śaktiṁ na prāpsyatha tāvatkālaṁ yirūśālamnagarē tiṣṭhata|
50 Ó sì mú wọn jáde lọ títí wọ́n fẹ́rẹ̀ dé Betani, nígbà tí ó sì gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè, ó súre fún wọn.
atha sa tān baithanīyāparyyantaṁ nītvā hastāvuttōlya āśiṣa vaktumārēbhē
51 Ó sì ṣe, bí ó ti ń súre fún wọn, ó yà kúrò lọ́dọ̀ wọn, a sì gbé e lọ sí ọ̀run.
āśiṣaṁ vadannēva ca tēbhyaḥ pr̥thag bhūtvā svargāya nītō'bhavat|
52 Wọ́n sì foríbalẹ̀ fún un, wọ́n sì padà lọ sí Jerusalẹmu pẹ̀lú ayọ̀ púpọ̀.
tadā tē taṁ bhajamānā mahānandēna yirūśālamaṁ pratyājagmuḥ|
53 Wọ́n sì wà ní tẹmpili nígbà gbogbo, wọ́n ń fi ìyìn, àti ìbùkún fún Ọlọ́run.
tatō nirantaraṁ mandirē tiṣṭhanta īśvarasya praśaṁsāṁ dhanyavādañca karttam ārēbhirē| iti||