< Luke 24 >
1 Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ ọ̀sẹ̀, àwọn obìnrin wá sí ibojì, wọ́n sì mú ìkunra olóòórùn dídùn ti wọ́n tí pèsè sílẹ̀ wá.
On the morowe after the saboth erly in the morninge they came vnto the toumbe and brought the odoures which they had prepared and other wemen with them
2 Òkúta ti yí kúrò ní ẹnu ibojì.
And they founde the stone rouled awaye fro the sepulcre
3 Nígbà tí wọ́n sì wọ inú rẹ̀, wọn kò rí òkú Jesu Olúwa.
and went in: but founde not the body of the Lorde Iesu.
4 Bí wọ́n ti dààmú kiri níhà ibẹ̀, kíyèsi i, àwọn ọkùnrin méjì aláṣọ dídán dúró tì wọ́n.
And it happened as they were amased therat: Beholde two men stode by them in shynynge vestures.
5 Nígbà tí ẹ̀rù ń bà wọ́n, tí wọ́n sì dojúbolẹ̀, àwọn angẹli náà bi wọ́n pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń wá alààyè láàrín àwọn òkú?
And as they were a frayde and bowed doune their faces to the erth: they sayd to them: why seke ye the lyvinge amonge the deed?
6 Kò sí níhìn-ín yìí, ṣùgbọ́n ó jíǹde; ẹ rántí bí ó ti wí fún yín nígbà tí ó wà ní Galili.
He is not here: but is rysen. Remember how he spake vnto you when he was yet with you in Galile
7 Pé, ‘A ó fi Ọmọ Ènìyàn lé àwọn ènìyàn ẹlẹ́ṣẹ̀ lọ́wọ́, a ó sì kàn án mọ́ àgbélébùú, ní ọjọ́ kẹta yóò sì jíǹde.’”
sayinge: that the sonne of man must be delyvered into the hondes of synfull men and be crucified and the thyrde daye ryse agayne.
8 Wọ́n sì rántí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
And they remembred his wordes
9 Wọ́n sì padà ti ibojì wá, wọ́n sì ròyìn gbogbo nǹkan wọ̀nyí fún àwọn mọ́kànlá, àti fún gbogbo àwọn ìyókù.
and returned from the sepulcre and tolde all these thinges vnto the eleven and to all the remanaunt.
10 Maria Magdalene, àti Joanna, àti Maria ìyá Jakọbu, àti àwọn mìíràn pẹ̀lú wọn sì ni àwọn tí ó ròyìn nǹkan wọ̀nyí fún àwọn aposteli.
It was Mary Magdalen and Ioanna and Mary Iacobi and other that were with the which tolde these thinges vnto the Apostles
11 Ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sì dàbí ìsọkúsọ lójú wọn, wọn kò sì gbà wọ́n gbọ́.
and their wordes semed vnto them fayned thinges nether beleved they them.
12 Nígbà náà ni Peteru dìde, ó súré lọ sí ibojì; nígbà tí ó sì bẹ̀rẹ̀, ó rí aṣọ àlà lọ́tọ̀ fúnra wọn, ó sì padà lọ sí ilé rẹ̀, ẹnu yà á sí ohun tí ó ṣe.
Then aroose Peter and ran vnto the sepulcre and stouped in and sawe the lynnen cloothes layde by them selfe and departed wondrynge in him selfe at that which had happened.
13 Sì kíyèsi i, àwọn méjì nínú wọn ń lọ ní ọjọ́ náà sí ìletò kan tí a ń pè ní Emmausi, tí ó jìnnà sí Jerusalẹmu níwọ̀n ọgọ́ta ibùsọ̀.
And beholde two of them went that same daye to a toune which was fro Ierusalem about thre scoore for longes called Emaus:
14 Wọ́n ń bá ara wọn sọ̀rọ̀ gbogbo nǹkan wọ̀nyí tí ó ṣẹlẹ̀.
and they talked togeder of all these thinges that had happened.
15 Ó sì ṣe, bí wọ́n ti ń bá ara wọn sọ̀rọ̀, tí wọ́n sì ń bá ara wọn jíròrò, Jesu tìkára rẹ̀ súnmọ́ wọn, ó sì ń bá wọn rìn lọ.
And it chaunsed as they comened togeder and reasoned that Iesus him selfe drue neare and went with them.
16 Ṣùgbọ́n a rú wọn lójú, kí wọn má le mọ̀ ọ́n.
But their eyes were holden that they coulde not knowe him.
17 Ó sì bi wọ́n pé, “Ọ̀rọ̀ kín ni ẹ̀yin ń bá ara yín sọ, bí ẹ̀yin ti ń rìn?” Wọ́n sì dúró jẹ́, wọ́n fajúro.
And he sayde vnto them: What maner of comunicacions are these that ye have one to another as ye walke and are sadde.
18 Ọ̀kan nínú wọn, tí a ń pè ní Kileopa, sì dáhùn wí fún un pé, “Àlejò sá à ni ìwọ ní Jerusalẹmu, tí ìwọ kò sì mọ ohun tí ó ṣẹ̀ níbẹ̀ ní ọjọ́ wọ̀nyí?”
And the one of them named Cleophas answered and sayd vnto him: arte thou only a straunger in Ierusalem and haste not knowen the thinges which have chaunsed therin in these dayes?
19 Ó sì bi wọ́n pé, “Kín ni?” Wọ́n sì wí fún un pé, “Ní ti Jesu ti Nasareti, ẹni tí ó jẹ́ wòlíì, tí ó pọ̀ ní ìṣe àti ní ọrọ̀ níwájú Ọlọ́run àti gbogbo ènìyàn,
To whom he sayd: what thinges? And they sayd vnto him: of Iesus of Nazareth which was a Prophet myghtie in dede and worde before god and all the people.
20 àti bí àwọn olórí àlùfáà àti àwọn alàgbà wa ti fi òun lé wọn lọ́wọ́ láti dá a lẹ́bi ikú, àti bí wọ́n ti kàn án mọ́ àgbélébùú.
And how the hye prestes and oure rulers delyvered him to be condempned to deeth: and have crucified him.
21 Bẹ́ẹ̀ ni òun ni àwa ti ní ìrètí pé, òun ni ìbá dá Israẹli ní ìdè. Àti pẹ̀lú gbogbo nǹkan wọ̀nyí, òní ni ó di ọjọ́ kẹta tí nǹkan wọ̀nyí ti ṣẹlẹ̀.
But we trusted that it shuld have bene he that shuld have delyvered Israel. And as touchynge all these thinges to daye is even the thyrd daye that they were done.
22 Àwọn obìnrin kan pẹ̀lú nínú ẹgbẹ́ wa, tí wọ́n lọ si ibojì ní kùtùkùtù, sì wá yà wá lẹ́nu,
Ye and certayne wemen also of oure company made vs astonyed which came erly vnto the sepulcre
23 nígbà tí wọn kò sì rí òkú rẹ̀, wọ́n wá wí pé, àwọn rí ìran àwọn angẹli tí wọ́n wí pé, ó wà láààyè.
and founde not his boddy: and came sayinge that they had sene a vision of angels which sayde that he was alyve.
24 Àti àwọn kan tí wọ́n wà pẹ̀lú wa lọ sí ibojì, wọ́n sì rí i gẹ́gẹ́ bí àwọn obìnrin náà ti wí, ṣùgbọ́n òun tìkára rẹ̀ ni wọn kò rí.”
And certayne of them which were with vs went their waye to the sepulcre and founde it even so as the wemen had sayde: but him they sawe not.
25 Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin tí òye kò yé, tí ẹ sì yigbì ní àyà láti gba gbogbo èyí tí àwọn wòlíì ti wí gbọ́,
And he sayde vnto the: O foles and slowe of herte to beleve all yt the prophetes have spoken.
26 kò ha yẹ kí Kristi ó jìyà nǹkan wọ̀nyí kí ó sì wọ inú ògo rẹ̀ lọ.”
Ought not Christ to have suffred these thinges and to enter into his glory?
27 Ó sì bẹ̀rẹ̀ láti Mose àti gbogbo àwọn wòlíì wá, ó sì túmọ̀ nǹkan fún wọn nínú ìwé mímọ́ gbogbo nípa ti ara rẹ̀.
And he began at Moses and at all the prophetes and interpreted vnto them in all scriptures which were wrytten of him.
28 Wọ́n sì súnmọ́ ìletò tí wọ́n ń lọ, ó sì ṣe bí ẹni pé yóò lọ sí iwájú.
And they drue neye vnto the toune wich they went to. And he made as though he wolde have gone further.
29 Wọ́n sì rọ̀ ọ́, pé, “Bá wa dúró: nítorí ó di ọjọ́ alẹ́, ọjọ́ sì kọjá tán.” Ó sì wọlé lọ, ó bá wọn dúró.
But they constrayned him sayinge: abyde with vs for it draweth towardes nyght and the daye is farre passed. And he went in to tary with the.
30 Ó sì ṣe, bí ó ti bá wọn jókòó ti oúnjẹ, ó mú àkàrà, ó súre sí i, ó sì bù ú, ó sì fi fún wọn.
And it came to passe as he sate at meate wt them he toke breed blessed it brake and gave to them.
31 Ojú wọn sì là, wọ́n sì mọ̀ ọ́n, ó sì nù mọ́ wọn ní ojú.
And their eyes were openned and they knewe him: and he vnnisshed out of their syght.
32 Wọ́n sì bá ara wọn sọ pé, “Ọkàn wa kò ha gbiná nínú wa, nígbà tí ó ń bá wa sọ̀rọ̀ tí ó sì ń túmọ̀ ìwé mímọ́ fún wa!”
And they sayde betwene them selves: dyd not oure hertes burne with in vs whyll he talked with vs by the waye and as he opened to vs the scriptures?
33 Wọ́n sì dìde ní wákàtí kan náà, wọ́n padà lọ sí Jerusalẹmu, wọ́n sì bá àwọn mọ́kànlá péjọ, àti àwọn tí ń bẹ lọ́dọ̀ wọn.
And they roose vp the same houre and returned agayne to Ierusalem and founde the eleven gadered to geder and them that were with them which
34 Wọn si wí pé, “Olúwa jíǹde nítòótọ́, ó sì ti fi ara hàn fún Simoni!”
sayde: the Lorde is rysen in dede and hath apered to Simon.
35 Àwọn náà sì ròyìn nǹkan tí ó ṣe ní ọ̀nà, àti bí ó ti di mí mọ̀ fún wọn ní bíbu àkàrà.
And they tolde what thinges was done in the waye and how they knewe him in breakynge of breed.
36 Bí wọ́n sì ti ń sọ nǹkan wọ̀nyí Jesu tìkára rẹ̀ dúró láàrín wọn, ó sì wí fún wọn pé, “Àlàáfíà fún yín.”
As they thus spake Iesus him selfe stode in ye myddes of them and sayde vnto them: peace be with you.
37 Ṣùgbọ́n àyà fò wọ́n, wọ́n sì wárìrì, wọ́n ṣe bí àwọn rí ẹ̀mí kan.
And they were abasshed and afrayde supposinge yt they had sene a sprete
38 Ó sì wí fún wọn pé, “Èéṣe tí ara yín kò lélẹ̀? Èé sì ti ṣe tí èròkerò fi ń sọ nínú ọkàn yín?
And he sayde vnto the: Why are ye troubled and why do thoughtes aryse in youre hertes?
39 Ẹ wo ọwọ́ mi àti ẹsẹ̀ mi, pé èmi tìkára mi ni! Ẹ dì mímú kí ẹ wò ó nítorí tí iwin kò ní ẹran àti egungun lára, bí ẹ̀yin ti rí tí èmi ní.”
Beholde my hondes and my fete that it is even my selfe. Handle me and se: for spretes have not flesshe and bones as ye se me have.
40 Nígbà tí ó sì wí bẹ́ẹ̀ tan, ó fi ọwọ́ àti ẹsẹ̀ rẹ̀ hàn wọ́n.
And when he had thus spoken he shewed them his hondes and his fete.
41 Nígbà tí wọn kò sì tí ì gbàgbọ́ fún ayọ̀, àti fún ìyanu, ó wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ní ohunkóhun jíjẹ níhìn-ín yìí?”
And whyll they yet beleved not for ioye and wondred he sayde vnto the: Have ye here eny meate?
42 Wọ́n sì fún un ní ẹja tí a fi oyin sè.
And they gave him a pece of a broyled fisshe and of an hony combe.
43 Ó sì gbà á, ó jẹ ẹ́ lójú wọn.
And he toke it and ate it before them.
44 Ó sì wí fún wọn pé, “Wọ̀nyí ni ọ̀rọ̀ tí mo sọ fún yín, nígbà tí èmí ti wà pẹ̀lú yín pé, a ní láti mú ohun gbogbo ṣẹ, tí a ti kọ nínú òfin Mose, àti nínú ìwé àwọn wòlíì, àti nínú Saamu, nípasẹ̀ mi.”
And he sayde vnto the. These are the wordes which I spake vnto you whyll I was yet with you: that all must be fulfilled which were written of me in the lawe of Moses and in the Prophetes and in the Psalmes.
45 Nígbà náà ni ó ṣí wọn ní iyè, kí ìwé mímọ́ lè yé wọn.
Then openned he their wyttes that they myght vnderstond the scriptures
46 Ó sì wí fún wọn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni a ti kọ̀wé rẹ̀, pé: kí Kristi jìyà, àti kí ó sì jíǹde ní ọjọ́ kẹta kúrò nínú òkú,
and sayde vnto them. Thus is it written and thus it behoved Christ to suffre and to ryse agayne from deeth the thyrde daye
47 àti pé kí a wàásù ìrònúpìwàdà àti ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀ lórúkọ rẹ̀, ní orílẹ̀-èdè gbogbo, bẹ̀rẹ̀ láti Jerusalẹmu lọ.
and that repentaunce and remission of synnes shuld be preached in his name amonge all nacions and must beginne at Ierusalem.
48 Ẹ̀yin sì ni ẹlẹ́rìí nǹkan wọ̀nyí.
And ye are witnesses of these thinges.
49 Èmi yóò rán ohun tí Baba mi ṣe ìlérí sí yín, ṣùgbọ́n ẹ jókòó ní ìlú Jerusalẹmu, títí a ó fífi agbára wọ̀ yín, láti òkè ọ̀run wá.”
And beholde I will sende the promes of my father apon you. But tary ye in ye cite of Ierusalem vntyll ye be endewed with power from an hye.
50 Ó sì mú wọn jáde lọ títí wọ́n fẹ́rẹ̀ dé Betani, nígbà tí ó sì gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè, ó súre fún wọn.
And he ledde the out into Bethany and lyfte vp his hondes and blest them.
51 Ó sì ṣe, bí ó ti ń súre fún wọn, ó yà kúrò lọ́dọ̀ wọn, a sì gbé e lọ sí ọ̀run.
And it cam to passe as he blessed the he departed from the and was caryed vp in to heven.
52 Wọ́n sì foríbalẹ̀ fún un, wọ́n sì padà lọ sí Jerusalẹmu pẹ̀lú ayọ̀ púpọ̀.
And they worshipped him and returned to Ierusalem with greate ioye
53 Wọ́n sì wà ní tẹmpili nígbà gbogbo, wọ́n ń fi ìyìn, àti ìbùkún fún Ọlọ́run.
and were continually in the temple praysinge and laudinge God. Amen.