< Luke 23 >
1 Gbogbo ìjọ ènìyàn sì dìde, wọ́n sì fà á lọ sí ọ̀dọ̀ Pilatu.
tataḥ sabhāsthāḥ sarvvalōkā utthāya taṁ pīlātasammukhaṁ nītvāprōdya vaktumārēbhirē,
2 Wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí fi ẹ̀sùn kàn án, wí pé, “Àwa rí ọkùnrin yìí ó ń yí orílẹ̀-èdè wa lọ́kàn padà, ó sì ń dá wọn lẹ́kun láti san owó òde fún Kesari, ó ń wí pé, òun tìkára òun ni Kristi ọba.”
svamabhiṣiktaṁ rājānaṁ vadantaṁ kaimararājāya karadānaṁ niṣēdhantaṁ rājyaviparyyayaṁ kurttuṁ pravarttamānam ēna prāptā vayaṁ|
3 Pilatu sì bi í léèrè, wí pé, “Ìwọ ha ni ọba àwọn Júù?” Ó sì dá a lóhùn wí pé, “Ìwọ wí i.”
tadā pīlātastaṁ pr̥ṣṭavān tvaṁ kiṁ yihūdīyānāṁ rājā? sa pratyuvāca tvaṁ satyamuktavān|
4 Pilatu sì wí fún àwọn olórí àlùfáà àti fún ìjọ ènìyàn pé, “Èmi kò rí ẹ̀ṣẹ̀ lọ́wọ́ ọkùnrin yìí.”
tadā pīlātaḥ pradhānayājakādilōkān jagād, ahamētasya kamapyaparādhaṁ nāptavān|
5 Wọ́n sì túbọ̀ tẹnumọ́ ọn pé, “Ó ń ru ènìyàn sókè, ó ń kọ́ni káàkiri gbogbo Judea, ó bẹ̀rẹ̀ láti Galili títí ó fi dé ìhín yìí!”
tatastē punaḥ sāhaminō bhūtvāvadan, ēṣa gālīla ētatsthānaparyyantē sarvvasmin yihūdādēśē sarvvāllōkānupadiśya kupravr̥ttiṁ grāhītavān|
6 Nígbà tí Pilatu gbọ́ orúkọ Galili, ó béèrè bí ọkùnrin náà bá jẹ́ ará Galili.
tadā pīlātō gālīlapradēśasya nāma śrutvā papraccha, kimayaṁ gālīlīyō lōkaḥ?
7 Nígbà tí ó sì mọ̀ pé ará ilẹ̀ abẹ́ àṣẹ Herodu ni, ó rán an sí Herodu, ẹni tí òun tìkára rẹ̀ wà ní Jerusalẹmu ní àkókò náà.
tataḥ sa gālīlpradēśīyahērōdrājasya tadā sthitēstasya samīpē yīśuṁ prēṣayāmāsa|
8 Nígbà tí Herodu, sì rí Jesu, ó yọ̀ gidigidi; nítorí tí ó ti ń fẹ́ rí i pẹ́ ó sá à ti ń gbọ́ ìròyìn púpọ̀ nítorí rẹ̀; ó sì ń retí láti rí i kí iṣẹ́ àmì díẹ̀ ti ọwọ́ rẹ̀ ṣe.
tadā hērōd yīśuṁ vilōkya santutōṣa, yataḥ sa tasya bahuvr̥ttāntaśravaṇāt tasya kiñicadāścaryyakarmma paśyati ityāśāṁ kr̥tvā bahukālamārabhya taṁ draṣṭuṁ prayāsaṁ kr̥tavān|
9 Ó sì béèrè ọ̀rọ̀ púpọ̀ lọ́wọ́ rẹ̀; ṣùgbọ́n kò da a lóhùn rárá.
tasmāt taṁ bahukathāḥ papraccha kintu sa tasya kasyāpi vākyasya pratyuttaraṁ nōvāca|
10 Àti àwọn olórí àlùfáà àti àwọn akọ̀wé dúró, wọ́n sì ń fi ẹ̀sùn kàn án gidigidi.
atha pradhānayājakā adhyāpakāśca prōttiṣṭhantaḥ sāhasēna tamapavadituṁ prārēbhirē|
11 Àti Herodu pẹ̀lú àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, wọ́n kẹ́gàn rẹ̀, wọ́n sì ń fi í ṣẹ̀sín, wọ́n wọ̀ ọ́ ní aṣọ dáradára, ó sì rán an padà tọ Pilatu lọ.
hērōd tasya sēnāgaṇaśca tamavajñāya upahāsatvēna rājavastraṁ paridhāpya punaḥ pīlātaṁ prati taṁ prāhiṇōt|
12 Pilatu àti Herodu di ọ̀rẹ́ ara wọn ní ọjọ́ náà, nítorí látijọ́ ọ̀tá ara wọn ni wọ́n ti jẹ́ rí.
pūrvvaṁ hērōdpīlātayōḥ parasparaṁ vairabhāva āsīt kintu taddinē dvayō rmēlanaṁ jātam|
13 Pilatu sì pe àwọn olórí àlùfáà àti àwọn olórí àti àwọn ènìyàn jọ.
paścāt pīlātaḥ pradhānayājakān śāsakān lōkāṁśca yugapadāhūya babhāṣē,
14 Ó sọ fún wọn pé, “Ẹyin mú ọkùnrin yìí tọ̀ mí wá, bí ẹni tí ó ń yí àwọn ènìyàn ní ọkàn padà. Sì kíyèsi i, èmí wádìí ẹjọ́ rẹ̀ níwájú yín èmi kò sì rí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ kan lọ́wọ́ ọkùnrin yìí, ní gbogbo nǹkan wọ̀nyí tí ẹ̀yin fi ẹ̀sùn rẹ̀ sùn.
rājyaviparyyayakārakōyam ityuktvā manuṣyamēnaṁ mama nikaṭamānaiṣṭa kintu paśyata yuṣmākaṁ samakṣam asya vicāraṁ kr̥tvāpi prōktāpavādānurūpēṇāsya kōpyaparādhaḥ sapramāṇō na jātaḥ,
15 Àti Herodu pẹ̀lú; ó sá rán an padà tọ̀ wá wá; sì kíyèsi i, ohun kan tí ó yẹ sí ikú ni a kò ṣe láti ọwọ́ rẹ̀.
yūyañca hērōdaḥ sannidhau prēṣitā mayā tatrāsya kōpyaparādhastēnāpi na prāptaḥ|paśyatānēna vadhahētukaṁ kimapi nāparāddhaṁ|
16 Ǹjẹ́ èmi ó nà án, èmi ó sì fi í sílẹ̀ lọ.”
tasmādēnaṁ tāḍayitvā vihāsyāmi|
tatrōtsavē tēṣāmēkō mōcayitavyaḥ|
18 Wọ́n sì kígbe sókè nígbà kan náà, pé, “Mú ọkùnrin yìí kúrò, kí o sì dá Baraba sílẹ̀ fún wa!”
iti hētōstē prōccairēkadā prōcuḥ, ēnaṁ dūrīkr̥tya barabbānāmānaṁ mōcaya|
19 Ẹni tí a sọ sínú túbú nítorí ọ̀tẹ̀ kan tí a ṣe ní ìlú, àti nítorí ìpànìyàn.
sa barabbā nagara upaplavavadhāparādhābhyāṁ kārāyāṁ baddha āsīt|
20 Pilatu sì tún bá wọn sọ̀rọ̀, nítorí ó fẹ́ dá Jesu sílẹ̀.
kintu pīlātō yīśuṁ mōcayituṁ vāñchan punastānuvāca|
21 Ṣùgbọ́n wọ́n kígbe, wí pé, “Kàn án mọ́ àgbélébùú, kàn án mọ àgbélébùú!”
tathāpyēnaṁ kruśē vyadha kruśē vyadhēti vadantastē ruruvuḥ|
22 Ó sì wí fún wọn lẹ́ẹ̀mẹ́ta pé, “Èéṣe, búburú kín ni ọkùnrin yìí ṣe? Èmi kò rí ọ̀ràn ikú lára rẹ̀: nítorí náà èmi ó nà án, èmi ó sì fi í sílẹ̀.”
tataḥ sa tr̥tīyavāraṁ jagāda kutaḥ? sa kiṁ karmma kr̥tavān? nāhamasya kamapi vadhāparādhaṁ prāptaḥ kēvalaṁ tāḍayitvāmuṁ tyajāmi|
23 Wọ́n túbọ̀ tẹramọ́ igbe ńlá, wọ́n ń fẹ́ kí a kàn án mọ́ àgbélébùú, ohùn tiwọn àti ti àwọn olórí àlùfáà borí tirẹ̀.
tathāpi tē punarēnaṁ kruśē vyadha ityuktvā prōccairdr̥ḍhaṁ prārthayāñcakrirē;
24 Pilatu sí fi àṣẹ sí i pé, kí ó rí bí wọ́n ti ń fẹ́.
tataḥ pradhānayājakādīnāṁ kalaravē prabalē sati tēṣāṁ prārthanārūpaṁ karttuṁ pīlāta ādidēśa|
25 Ó sì dá ẹni tí wọ́n fẹ́ sílẹ̀ fún wọn, ẹni tí a tìtorí ọ̀tẹ̀ àti ìpànìyàn sọ sínú túbú; ṣùgbọ́n ó fi Jesu lé wọn lọ́wọ́.
rājadrōhavadhayōraparādhēna kārāsthaṁ yaṁ janaṁ tē yayācirē taṁ mōcayitvā yīśuṁ tēṣāmicchāyāṁ samārpayat|
26 Bí wọ́n sì ti ń fà á lọ, wọ́n mú ọkùnrin kan, Simoni ara Kirene, tí ó ń ti ìgbèríko bọ̀, òun ni wọ́n sì gbé àgbélébùú náà lé, kí ó máa rù ú lọ tẹ̀lé Jesu.
atha tē yīśuṁ gr̥hītvā yānti, ētarhi grāmādāgataṁ śimōnanāmānaṁ kurīṇīyaṁ janaṁ dhr̥tvā yīśōḥ paścānnētuṁ tasya skandhē kruśamarpayāmāsuḥ|
27 Ìjọ ènìyàn púpọ̀ ni ó ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, àti àwọn obìnrin, tí ń pohùnréré ẹkún,
tatō lōkāraṇyamadhyē bahustriyō rudatyō vilapantyaśca yīśōḥ paścād yayuḥ|
28 ṣùgbọ́n Jesu yíjú padà sí wọn, ó sì wí pé, “Ẹ̀yin ọmọbìnrin Jerusalẹmu, ẹ má sọkún fún mi, ṣùgbọ́n ẹ sọkún fún ara yín, àti fún àwọn ọmọ yín.
kintu sa vyāghuṭya tā uvāca, hē yirūśālamō nāryyō yuyaṁ madarthaṁ na ruditvā svārthaṁ svāpatyārthañca ruditi;
29 Nítorí kíyèsi i, ọjọ́ ń bọ̀ ní èyí tí ẹ̀yin ó wí pé, ‘Ìbùkún ni fún àgàn, àti fún inú tí kò bímọ rí, àti fún ọmú tí kò fún ni mu rí!’
paśyata yaḥ kadāpi garbhavatyō nābhavan stanyañca nāpāyayan tādr̥śī rvandhyā yadā dhanyā vakṣyanti sa kāla āyāti|
30 Nígbà náà ni “‘wọn ó bẹ̀rẹ̀ sí wí fún àwọn òkè kéékèèké pé, “Yí lù wá!” Sí àwọn òkè ńlá, “Bò wá mọ́lẹ̀!”’
tadā hē śailā asmākamupari patata, hē upaśailā asmānācchādayata kathāmīdr̥śīṁ lōkā vakṣyanti|
31 Nítorí bí wọn bá ń ṣe nǹkan wọ̀nyí sára igi tútù, kín ni a ó ṣe sára igi gbígbẹ?”
yataḥ satējasi śākhini cēdētad ghaṭatē tarhi śuṣkaśākhini kiṁ na ghaṭiṣyatē?
32 Àwọn méjì mìíràn bákan náà, àwọn arúfin, ni wọ́n sì fà lọ pẹ̀lú rẹ̀ láti pa.
tadā tē hantuṁ dvāvaparādhinau tēna sārddhaṁ ninyuḥ|
33 Nígbà tí wọ́n sì dé ibi tí a ń pè ní Agbárí, níbẹ̀ ni wọ́n gbé kàn án mọ́ àgbélébùú, àti àwọn arúfin náà, ọ̀kan ní ọwọ́ ọ̀tún, àti ọ̀kan ní ọwọ́ òsì.
aparaṁ śiraḥkapālanāmakasthānaṁ prāpya taṁ kruśē vividhuḥ; taddvayōraparādhinōrēkaṁ tasya dakṣiṇō tadanyaṁ vāmē kruśē vividhuḥ|
34 Jesu sì wí pé, “Baba, dáríjì wọ́n; nítorí tí wọn kò mọ ohun tí wọ́n ń ṣe.” Wọ́n di ìbò láti pín aṣọ rẹ̀ láàrín ara wọn.
tadā yīśurakathayat, hē pitarētān kṣamasva yata ētē yat karmma kurvvanti tan na viduḥ; paścāttē guṭikāpātaṁ kr̥tvā tasya vastrāṇi vibhajya jagr̥huḥ|
35 Àwọn ènìyàn sì dúró láti wòran. Àti àwọn ìjòyè pẹ̀lú wọn, wọ́n ń yọ ṣùtì sí i, wí pé, “Ó gba àwọn ẹlòmíràn là; kí ó gbara rẹ̀ là, bí ó bá ṣe Kristi, àyànfẹ́ Ọlọ́run.”
tatra lōkasaṁghastiṣṭhan dadarśa; tē tēṣāṁ śāsakāśca tamupahasya jagaduḥ, ēṣa itarān rakṣitavān yadīśvarēṇābhirucitō 'bhiṣiktastrātā bhavati tarhi svamadhunā rakṣatu|
36 Àti àwọn ọmọ-ogun pẹ̀lú ń fi í ṣe ẹlẹ́yà, wọ́n tọ̀ ọ́ wá, wọ́n ń fi ọtí kíkan fún un.
tadanyaḥ sēnāgaṇā ētya tasmai amlarasaṁ datvā parihasya prōvāca,
37 Wọ́n sì ń wí pé, “Bí ìwọ bá ṣe ọba àwọn Júù, gba ara rẹ là.”
cēttvaṁ yihūdīyānāṁ rājāsi tarhi svaṁ rakṣa|
38 Wọ́n sì kọ̀wé àkọlé sí ìgbèrí rẹ̀ ní èdè Giriki, àti ti Latin, àti tí Heberu pe: Èyí ni Ọba àwọn Júù.
yihūdīyānāṁ rājēti vākyaṁ yūnānīyarōmīyēbrīyākṣarai rlikhitaṁ tacchirasa ūrddhvē'sthāpyata|
39 Àti ọ̀kan nínú àwọn arúfin tí a gbé kọ́ ń fi ṣe ẹlẹ́yà wí pé, “Bí ìwọ bá ṣe Kristi, gba ara rẹ àti àwa náà là.”
tadōbhayapārśvayō rviddhau yāvaparādhinau tayōrēkastaṁ vinindya babhāṣē, cēttvam abhiṣiktōsi tarhi svamāvāñca rakṣa|
40 Ṣùgbọ́n èyí èkejì dáhùn, ó ń bá a wí pé, “Ìwọ kò bẹ̀rù Ọlọ́run, tí ìwọ wà nínú ẹ̀bi kan náà?
kintvanyastaṁ tarjayitvāvadat, īśvarāttava kiñcidapi bhayaṁ nāsti kiṁ? tvamapi samānadaṇḍōsi,
41 Ní tiwa, wọ́n jàre nítorí èrè ohun tí àwa ṣe ni à ń jẹ, ṣùgbọ́n ọkùnrin yìí kò ṣe ohun búburú kan.”
yōgyapātrē āvāṁ svasvakarmmaṇāṁ samucitaphalaṁ prāpnuvaḥ kintvanēna kimapi nāparāddhaṁ|
42 Ó sì wí pé, “Jesu, rántí mi nígbà tí ìwọ bá dé ìjọba rẹ.”
atha sa yīśuṁ jagāda hē prabhē bhavān svarājyapravēśakālē māṁ smaratu|
43 Jesu sì wí fún un pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún ọ, lónìí ni ìwọ ó wà pẹ̀lú mi ní Paradise!”
tadā yīśuḥ kathitavān tvāṁ yathārthaṁ vadāmi tvamadyaiva mayā sārddhaṁ paralōkasya sukhasthānaṁ prāpsyasi|
44 Ó sì tó ìwọ̀n wákàtí kẹfà ọjọ́, òkùnkùn sì ṣú bo gbogbo ilẹ̀ títí ó fi di wákàtí kẹsànán ọjọ́.
aparañca dvitīyayāmāt tr̥tīyayāmaparyyantaṁ ravēstējasōntarhitatvāt sarvvadēśō'ndhakārēṇāvr̥tō
45 Òòrùn sì ṣú òòkùn, aṣọ ìkélé ti tẹmpili sì ya ní àárín méjì.
mandirasya yavanikā ca chidyamānā dvidhā babhūva|
46 Nígbà tí Jesu sì kígbe lóhùn rara, ó ní, “Baba, ní ọwọ́ rẹ ni mo fi ẹ̀mí mi lé!” Nígbà tí ó sì wí èyí tan, ó jọ̀wọ́ ẹ̀mí rẹ̀.
tatō yīśuruccairuvāca, hē pita rmamātmānaṁ tava karē samarpayē, ityuktvā sa prāṇān jahau|
47 Nígbà tí balógun ọ̀rún rí ohun tí ó ṣe, ó yin Ọlọ́run lógo, wí pé, “Dájúdájú olódodo ni ọkùnrin yìí!”
tadaitā ghaṭanā dr̥ṣṭvā śatasēnāpatirīśvaraṁ dhanyamuktvā kathitavān ayaṁ nitāntaṁ sādhumanuṣya āsīt|
48 Gbogbo ìjọ ènìyàn tí ó péjọ láti rí ìran yìí, nígbà tí wọ́n rí ohun tí ó ṣẹlẹ̀ wọ́n lu ara wọn ní oókan àyà, wọ́n sì padà sí ilé.
atha yāvantō lōkā draṣṭum āgatāstē tā ghaṭanā dr̥ṣṭvā vakṣaḥsu karāghātaṁ kr̥tvā vyācuṭya gatāḥ|
49 Àti gbogbo àwọn ojúlùmọ̀ rẹ̀, àti àwọn obìnrin tí ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn láti Galili wá, wọ́n dúró lókèèrè, wọ́n ń wo nǹkan wọ̀nyí.
yīśō rjñātayō yā yā yōṣitaśca gālīlastēna sārddhamāyātāstā api dūrē sthitvā tat sarvvaṁ dadr̥śuḥ|
50 Sì kíyèsi i, ọkùnrin kan tí a ń pè ní Josẹfu, láti ìlú àwọn Júù kan tí ń jẹ́ Arimatea. Ó jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ọmọ ìgbìmọ̀, ènìyàn rere, àti olóòtítọ́.
tadā yihūdīyānāṁ mantraṇāṁ kriyāñcāsammanyamāna īśvarasya rājatvam apēkṣamāṇō
51 Òun kò bá wọn fi ohùn sí ìmọ̀ àti ìṣe wọn; Ó wá láti Judea, ìlú àwọn ará Arimatea, òun pẹ̀lú ń retí ìjọba Ọlọ́run.
yihūdidēśīyō 'rimathīyanagarīyō yūṣaphnāmā mantrī bhadrō dhārmmikaśca pumān
52 Ọkùnrin yìí tọ Pilatu lọ, ó sì tọrọ òkú Jesu.
pīlātāntikaṁ gatvā yīśō rdēhaṁ yayācē|
53 Nígbà tí ó sì sọ̀ ọ́ kalẹ̀, ó sì fi aṣọ àlà dì í, ó sì tẹ́ ẹ sínú ibojì tí a gbẹ́ nínú Òkúta, níbi tí a kò tẹ́ ẹnikẹ́ni sí rí.
paścād vapuravarōhya vāsasā saṁvēṣṭya yatra kōpi mānuṣō nāsthāpyata tasmin śailē svātē śmaśānē tadasthāpayat|
54 Ó sì jẹ́ ọjọ́ ìpalẹ̀mọ́, ọjọ́ ìsinmi sì kù sí dẹ̀dẹ̀.
taddinamāyōjanīyaṁ dinaṁ viśrāmavāraśca samīpaḥ|
55 Àti àwọn obìnrin, tí wọ́n bá a ti Galili wá, tí wọ́n sì tẹ̀lé, wọ́n kíyèsi ibojì náà, àti bí a ti tẹ́ òkú rẹ̀ sílẹ̀.
aparaṁ yīśunā sārddhaṁ gālīla āgatā yōṣitaḥ paścāditvā śmaśānē tatra yathā vapuḥ sthāpitaṁ tacca dr̥ṣṭvā
56 Nígbà tí wọ́n sì padà, wọ́n pèsè ohun olóòórùn dídùn, òróró ìkunra (àti tùràrí tútù); wọ́n sì sinmi ní ọjọ́ ìsinmi gẹ́gẹ́ bí òfin.
vyāghuṭya sugandhidravyatailāni kr̥tvā vidhivad viśrāmavārē viśrāmaṁ cakruḥ|