< Luke 23 >

1 Gbogbo ìjọ ènìyàn sì dìde, wọ́n sì fà á lọ sí ọ̀dọ̀ Pilatu.
Wtedy całe to zgromadzenie powstało i zaprowadzili go do Piłata.
2 Wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí fi ẹ̀sùn kàn án, wí pé, “Àwa rí ọkùnrin yìí ó ń yí orílẹ̀-èdè wa lọ́kàn padà, ó sì ń dá wọn lẹ́kun láti san owó òde fún Kesari, ó ń wí pé, òun tìkára òun ni Kristi ọba.”
I zaczęli go oskarżać, mówiąc: Zastaliśmy tego [człowieka], jak odwracał naród i zakazywał płacić podatki cesarzowi, mówiąc, że on jest Chrystusem, królem.
3 Pilatu sì bi í léèrè, wí pé, “Ìwọ ha ni ọba àwọn Júù?” Ó sì dá a lóhùn wí pé, “Ìwọ wí i.”
Piłat zapytał go: Czy ty jesteś królem Żydów? A on mu odpowiedział: Ty [sam to] mówisz.
4 Pilatu sì wí fún àwọn olórí àlùfáà àti fún ìjọ ènìyàn pé, “Èmi kò rí ẹ̀ṣẹ̀ lọ́wọ́ ọkùnrin yìí.”
Wtedy Piłat powiedział do naczelnych kapłanów i do ludu: Nie znajduję żadnej winy w tym człowieku.
5 Wọ́n sì túbọ̀ tẹnumọ́ ọn pé, “Ó ń ru ènìyàn sókè, ó ń kọ́ni káàkiri gbogbo Judea, ó bẹ̀rẹ̀ láti Galili títí ó fi dé ìhín yìí!”
Lecz oni [jeszcze] bardziej nastawali, mówiąc: Podburza lud, nauczając po całej Judei, począwszy od Galilei aż dotąd.
6 Nígbà tí Pilatu gbọ́ orúkọ Galili, ó béèrè bí ọkùnrin náà bá jẹ́ ará Galili.
Kiedy Piłat usłyszał o Galilei, zapytał, czy człowiek ten jest Galilejczykiem.
7 Nígbà tí ó sì mọ̀ pé ará ilẹ̀ abẹ́ àṣẹ Herodu ni, ó rán an sí Herodu, ẹni tí òun tìkára rẹ̀ wà ní Jerusalẹmu ní àkókò náà.
A gdy się dowiedział, że podlega władzy Heroda, odesłał go do Heroda, który w tych dniach również był w Jerozolimie.
8 Nígbà tí Herodu, sì rí Jesu, ó yọ̀ gidigidi; nítorí tí ó ti ń fẹ́ rí i pẹ́ ó sá à ti ń gbọ́ ìròyìn púpọ̀ nítorí rẹ̀; ó sì ń retí láti rí i kí iṣẹ́ àmì díẹ̀ ti ọwọ́ rẹ̀ ṣe.
Na widok Jezusa Herod bardzo się ucieszył. Od dawna bowiem pragnął go zobaczyć, ponieważ wiele o nim słyszał i spodziewał się, że ujrzy jakiś cud przez niego dokonany.
9 Ó sì béèrè ọ̀rọ̀ púpọ̀ lọ́wọ́ rẹ̀; ṣùgbọ́n kò da a lóhùn rárá.
I zadawał mu wiele pytań, lecz on mu nic nie odpowiedział.
10 Àti àwọn olórí àlùfáà àti àwọn akọ̀wé dúró, wọ́n sì ń fi ẹ̀sùn kàn án gidigidi.
A naczelni kapłani i uczeni w Piśmie stali [tam] i gwałtownie go oskarżali.
11 Àti Herodu pẹ̀lú àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, wọ́n kẹ́gàn rẹ̀, wọ́n sì ń fi í ṣẹ̀sín, wọ́n wọ̀ ọ́ ní aṣọ dáradára, ó sì rán an padà tọ Pilatu lọ.
Wtedy Herod ze swymi żołnierzami wzgardził nim i naśmiewał się z niego, ubierając go w białą szatę, i odesłał z powrotem do Piłata.
12 Pilatu àti Herodu di ọ̀rẹ́ ara wọn ní ọjọ́ náà, nítorí látijọ́ ọ̀tá ara wọn ni wọ́n ti jẹ́ rí.
W tym dniu Piłat i Herod stali się przyjaciółmi. Przedtem bowiem byli sobie wrogami.
13 Pilatu sì pe àwọn olórí àlùfáà àti àwọn olórí àti àwọn ènìyàn jọ.
A Piłat, zwoławszy naczelnych kapłanów, przełożonych oraz lud;
14 Ó sọ fún wọn pé, “Ẹyin mú ọkùnrin yìí tọ̀ mí wá, bí ẹni tí ó ń yí àwọn ènìyàn ní ọkàn padà. Sì kíyèsi i, èmí wádìí ẹjọ́ rẹ̀ níwájú yín èmi kò sì rí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ kan lọ́wọ́ ọkùnrin yìí, ní gbogbo nǹkan wọ̀nyí tí ẹ̀yin fi ẹ̀sùn rẹ̀ sùn.
Powiedział do nich: Przyprowadziliście mi tego człowieka jako podburzającego lud. Otóż ja przesłuchałem [go] wobec was i nie znalazłem w tym człowieku żadnej winy w sprawach, o które go oskarżacie;
15 Àti Herodu pẹ̀lú; ó sá rán an padà tọ̀ wá wá; sì kíyèsi i, ohun kan tí ó yẹ sí ikú ni a kò ṣe láti ọwọ́ rẹ̀.
Ani też Herod. Odesłałem was bowiem do niego i nie znalazł w nim nic, co zasługiwałoby na śmierć.
16 Ǹjẹ́ èmi ó nà án, èmi ó sì fi í sílẹ̀ lọ.”
Ubiczuję go więc i wypuszczę.
Piłat bowiem miał obowiązek wypuszczać im jednego [więźnia] na święto.
18 Wọ́n sì kígbe sókè nígbà kan náà, pé, “Mú ọkùnrin yìí kúrò, kí o sì dá Baraba sílẹ̀ fún wa!”
Wtedy wszyscy razem zawołali: Strać tego [człowieka], a wypuść nam Barabasza!
19 Ẹni tí a sọ sínú túbú nítorí ọ̀tẹ̀ kan tí a ṣe ní ìlú, àti nítorí ìpànìyàn.
Był on wtrącony do więzienia za jakiś rozruch wywołany w mieście i za zabójstwo.
20 Pilatu sì tún bá wọn sọ̀rọ̀, nítorí ó fẹ́ dá Jesu sílẹ̀.
Wtedy Piłat znowu przemówił, chcąc wypuścić Jezusa.
21 Ṣùgbọ́n wọ́n kígbe, wí pé, “Kàn án mọ́ àgbélébùú, kàn án mọ àgbélébùú!”
Oni jednak wołali: Ukrzyżuj, ukrzyżuj go!
22 Ó sì wí fún wọn lẹ́ẹ̀mẹ́ta pé, “Èéṣe, búburú kín ni ọkùnrin yìí ṣe? Èmi kò rí ọ̀ràn ikú lára rẹ̀: nítorí náà èmi ó nà án, èmi ó sì fi í sílẹ̀.”
A on po raz trzeci powiedział do nich: Cóż on złego uczynił? Nie znalazłem w nim nic, co zasługuje na śmierć. Ubiczuję go więc i wypuszczę.
23 Wọ́n túbọ̀ tẹramọ́ igbe ńlá, wọ́n ń fẹ́ kí a kàn án mọ́ àgbélébùú, ohùn tiwọn àti ti àwọn olórí àlùfáà borí tirẹ̀.
Lecz oni nalegali donośnym głosem, domagając się, aby go ukrzyżowano. I wzmagały się głosy ich i naczelnych kapłanów.
24 Pilatu sí fi àṣẹ sí i pé, kí ó rí bí wọ́n ti ń fẹ́.
Piłat więc zawyrokował, aby stało się według ich żądania.
25 Ó sì dá ẹni tí wọ́n fẹ́ sílẹ̀ fún wọn, ẹni tí a tìtorí ọ̀tẹ̀ àti ìpànìyàn sọ sínú túbú; ṣùgbọ́n ó fi Jesu lé wọn lọ́wọ́.
I uwolnił im [tego], o którego prosili, a który został wtrącony do więzienia za rozruch i zabójstwo. Jezusa zaś zdał na ich wolę.
26 Bí wọ́n sì ti ń fà á lọ, wọ́n mú ọkùnrin kan, Simoni ara Kirene, tí ó ń ti ìgbèríko bọ̀, òun ni wọ́n sì gbé àgbélébùú náà lé, kí ó máa rù ú lọ tẹ̀lé Jesu.
A gdy go prowadzili, zatrzymali niejakiego Szymona z Cyreny, który szedł z pola, i włożyli na niego krzyż, aby [go] niósł za Jezusem.
27 Ìjọ ènìyàn púpọ̀ ni ó ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, àti àwọn obìnrin, tí ń pohùnréré ẹkún,
I szło za nim wielkie mnóstwo ludzi i kobiet, które płakały nad nim i zawodziły.
28 ṣùgbọ́n Jesu yíjú padà sí wọn, ó sì wí pé, “Ẹ̀yin ọmọbìnrin Jerusalẹmu, ẹ má sọkún fún mi, ṣùgbọ́n ẹ sọkún fún ara yín, àti fún àwọn ọmọ yín.
Ale Jezus zwrócił się do nich i powiedział: Córki Jerozolimy, nie płaczcie nade mną, ale raczej płaczcie nad sobą i nad waszymi dziećmi.
29 Nítorí kíyèsi i, ọjọ́ ń bọ̀ ní èyí tí ẹ̀yin ó wí pé, ‘Ìbùkún ni fún àgàn, àti fún inú tí kò bímọ rí, àti fún ọmú tí kò fún ni mu rí!’
Oto bowiem idą dni, kiedy będą mówić: Błogosławione niepłodne, łona, które nie rodziły, i piersi, które nie karmiły.
30 Nígbà náà ni “‘wọn ó bẹ̀rẹ̀ sí wí fún àwọn òkè kéékèèké pé, “Yí lù wá!” Sí àwọn òkè ńlá, “Bò wá mọ́lẹ̀!”’
Wtedy zaczną mówić do gór: Padnijcie na nas! A do pagórków: Przykryjcie nas!
31 Nítorí bí wọn bá ń ṣe nǹkan wọ̀nyí sára igi tútù, kín ni a ó ṣe sára igi gbígbẹ?”
Bo jeśli na zielonym drzewie tak się dzieje, cóż będzie na suchym?
32 Àwọn méjì mìíràn bákan náà, àwọn arúfin, ni wọ́n sì fà lọ pẹ̀lú rẹ̀ láti pa.
Prowadzono też dwóch innych, złoczyńców, aby razem z nim zostali straceni.
33 Nígbà tí wọ́n sì dé ibi tí a ń pè ní Agbárí, níbẹ̀ ni wọ́n gbé kàn án mọ́ àgbélébùú, àti àwọn arúfin náà, ọ̀kan ní ọwọ́ ọ̀tún, àti ọ̀kan ní ọwọ́ òsì.
A gdy przyszli na miejsce zwane [Miejscem] Czaszki, ukrzyżowali tam jego i złoczyńców, jednego po prawej, a drugiego po lewej stronie.
34 Jesu sì wí pé, “Baba, dáríjì wọ́n; nítorí tí wọn kò mọ ohun tí wọ́n ń ṣe.” Wọ́n di ìbò láti pín aṣọ rẹ̀ láàrín ara wọn.
Wtedy Jezus powiedział: Ojcze, przebacz im, bo nie wiedzą, co czynią. Potem podzielili jego szaty i rzucali [o nie] losy.
35 Àwọn ènìyàn sì dúró láti wòran. Àti àwọn ìjòyè pẹ̀lú wọn, wọ́n ń yọ ṣùtì sí i, wí pé, “Ó gba àwọn ẹlòmíràn là; kí ó gbara rẹ̀ là, bí ó bá ṣe Kristi, àyànfẹ́ Ọlọ́run.”
A lud stał i przypatrywał się, i wraz z przełożonymi naśmiewał się z niego, mówiąc: Innych ratował, niech ratuje samego siebie, jeśli on jest Chrystusem, wybranym Boga.
36 Àti àwọn ọmọ-ogun pẹ̀lú ń fi í ṣe ẹlẹ́yà, wọ́n tọ̀ ọ́ wá, wọ́n ń fi ọtí kíkan fún un.
Naśmiewali się z niego również żołnierze, podchodząc i podając mu ocet;
37 Wọ́n sì ń wí pé, “Bí ìwọ bá ṣe ọba àwọn Júù, gba ara rẹ là.”
I mówili: Jeśli ty jesteś królem Żydów, ratuj samego siebie.
38 Wọ́n sì kọ̀wé àkọlé sí ìgbèrí rẹ̀ ní èdè Giriki, àti ti Latin, àti tí Heberu pe: Èyí ni Ọba àwọn Júù.
Był też nad nim napis sporządzony w języku greckim, łacińskim i hebrajskim: To jest król Żydów.
39 Àti ọ̀kan nínú àwọn arúfin tí a gbé kọ́ ń fi ṣe ẹlẹ́yà wí pé, “Bí ìwọ bá ṣe Kristi, gba ara rẹ àti àwa náà là.”
A jeden z tych złoczyńców, którzy z nim wisieli, urągał mu: Jeśli ty jesteś Chrystusem, ratuj siebie i nas.
40 Ṣùgbọ́n èyí èkejì dáhùn, ó ń bá a wí pé, “Ìwọ kò bẹ̀rù Ọlọ́run, tí ìwọ wà nínú ẹ̀bi kan náà?
Lecz drugi odezwał się, gromiąc go słowami: I ty się Boga nie boisz, chociaż ponosisz tę samą karę?
41 Ní tiwa, wọ́n jàre nítorí èrè ohun tí àwa ṣe ni à ń jẹ, ṣùgbọ́n ọkùnrin yìí kò ṣe ohun búburú kan.”
My doprawdy – sprawiedliwie, bo odbieramy należną zapłatę za nasze uczynki, ale on nic złego nie zrobił.
42 Ó sì wí pé, “Jesu, rántí mi nígbà tí ìwọ bá dé ìjọba rẹ.”
I powiedział do Jezusa: Panie, wspomnij na mnie, gdy przyjdziesz do swego królestwa.
43 Jesu sì wí fún un pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún ọ, lónìí ni ìwọ ó wà pẹ̀lú mi ní Paradise!”
A Jezus mu odpowiedział: Zaprawdę powiadam ci: Dziś będziesz ze mną w raju.
44 Ó sì tó ìwọ̀n wákàtí kẹfà ọjọ́, òkùnkùn sì ṣú bo gbogbo ilẹ̀ títí ó fi di wákàtí kẹsànán ọjọ́.
A było około godziny szóstej i ciemność ogarnęła całą ziemię aż do godziny dziewiątej.
45 Òòrùn sì ṣú òòkùn, aṣọ ìkélé ti tẹmpili sì ya ní àárín méjì.
I zaćmiło się słońce, a zasłona świątyni rozerwała się przez środek.
46 Nígbà tí Jesu sì kígbe lóhùn rara, ó ní, “Baba, ní ọwọ́ rẹ ni mo fi ẹ̀mí mi lé!” Nígbà tí ó sì wí èyí tan, ó jọ̀wọ́ ẹ̀mí rẹ̀.
Wtedy Jezus zawołał donośnym głosem: Ojcze, w twoje ręce powierzam mego ducha. Gdy to powiedział, skonał.
47 Nígbà tí balógun ọ̀rún rí ohun tí ó ṣe, ó yin Ọlọ́run lógo, wí pé, “Dájúdájú olódodo ni ọkùnrin yìí!”
A setnik, widząc, co się działo, chwalił Boga, mówiąc: Istotnie, to był sprawiedliwy człowiek.
48 Gbogbo ìjọ ènìyàn tí ó péjọ láti rí ìran yìí, nígbà tí wọ́n rí ohun tí ó ṣẹlẹ̀ wọ́n lu ara wọn ní oókan àyà, wọ́n sì padà sí ilé.
Także i wszyscy ludzie, którzy zeszli się na to widowisko, gdy zobaczyli, co się stało, bili się w piersi i zawracali.
49 Àti gbogbo àwọn ojúlùmọ̀ rẹ̀, àti àwọn obìnrin tí ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn láti Galili wá, wọ́n dúró lókèèrè, wọ́n ń wo nǹkan wọ̀nyí.
Wszyscy zaś jego znajomi stali z daleka, przypatrując się temu, również kobiety, które przyszły za nim z Galilei.
50 Sì kíyèsi i, ọkùnrin kan tí a ń pè ní Josẹfu, láti ìlú àwọn Júù kan tí ń jẹ́ Arimatea. Ó jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ọmọ ìgbìmọ̀, ènìyàn rere, àti olóòtítọ́.
A był tam człowiek imieniem Józef, który był członkiem Rady, człowiek dobry i sprawiedliwy.
51 Òun kò bá wọn fi ohùn sí ìmọ̀ àti ìṣe wọn; Ó wá láti Judea, ìlú àwọn ará Arimatea, òun pẹ̀lú ń retí ìjọba Ọlọ́run.
Nie zgadzał się on z ich uchwałą i czynem. Pochodził z Arymatei, miasta żydowskiego, i oczekiwał królestwa Bożego.
52 Ọkùnrin yìí tọ Pilatu lọ, ó sì tọrọ òkú Jesu.
Przyszedł on do Piłata i poprosił o ciało Jezusa.
53 Nígbà tí ó sì sọ̀ ọ́ kalẹ̀, ó sì fi aṣọ àlà dì í, ó sì tẹ́ ẹ sínú ibojì tí a gbẹ́ nínú Òkúta, níbi tí a kò tẹ́ ẹnikẹ́ni sí rí.
Zdjął je, owinął płótnem i położył w grobowcu wykutym [w skale], w którym jeszcze nikt nigdy nie był złożony.
54 Ó sì jẹ́ ọjọ́ ìpalẹ̀mọ́, ọjọ́ ìsinmi sì kù sí dẹ̀dẹ̀.
A był to dzień przygotowania i zbliżał się szabat.
55 Àti àwọn obìnrin, tí wọ́n bá a ti Galili wá, tí wọ́n sì tẹ̀lé, wọ́n kíyèsi ibojì náà, àti bí a ti tẹ́ òkú rẹ̀ sílẹ̀.
Poszły też za nim kobiety, które przybyły z nim z Galilei. Zobaczyły grobowiec i jak złożono jego ciało.
56 Nígbà tí wọ́n sì padà, wọ́n pèsè ohun olóòórùn dídùn, òróró ìkunra (àti tùràrí tútù); wọ́n sì sinmi ní ọjọ́ ìsinmi gẹ́gẹ́ bí òfin.
A gdy wróciły, przygotowały wonności i olejki. Lecz w szabat odpoczywały zgodnie z przykazaniem.

< Luke 23 >