< Luke 23 >

1 Gbogbo ìjọ ènìyàn sì dìde, wọ́n sì fà á lọ sí ọ̀dọ̀ Pilatu.
Tedy powstawszy wszystko mnóstwo ich, wiedli go do Piłata.
2 Wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí fi ẹ̀sùn kàn án, wí pé, “Àwa rí ọkùnrin yìí ó ń yí orílẹ̀-èdè wa lọ́kàn padà, ó sì ń dá wọn lẹ́kun láti san owó òde fún Kesari, ó ń wí pé, òun tìkára òun ni Kristi ọba.”
I poczęli nań skarżyć, mówiąc: Tegośmy znaleźli, że odwraca lud i zakazuje dani dawać cesarzowi, powiadając: Że on jest Chrystusem królem.
3 Pilatu sì bi í léèrè, wí pé, “Ìwọ ha ni ọba àwọn Júù?” Ó sì dá a lóhùn wí pé, “Ìwọ wí i.”
I pytał go Piłat, mówiąc: Tyżeś jest on król żydowski? A on mu odpowiadając rzekł: Ty powiadasz.
4 Pilatu sì wí fún àwọn olórí àlùfáà àti fún ìjọ ènìyàn pé, “Èmi kò rí ẹ̀ṣẹ̀ lọ́wọ́ ọkùnrin yìí.”
I rzekł Piłat do przedniejszych kapłanów i do ludu: Żadnej winy nie znajduję w tym człowieku.
5 Wọ́n sì túbọ̀ tẹnumọ́ ọn pé, “Ó ń ru ènìyàn sókè, ó ń kọ́ni káàkiri gbogbo Judea, ó bẹ̀rẹ̀ láti Galili títí ó fi dé ìhín yìí!”
Lecz się oni bardziej silili, mówiąc: Iż wzrusza lud, ucząc po wszystkiej Judzkiej ziemi, począwszy od Galilei aż dotąd.
6 Nígbà tí Pilatu gbọ́ orúkọ Galili, ó béèrè bí ọkùnrin náà bá jẹ́ ará Galili.
Tedy Piłat usłyszawszy o Galilei, pytał, jeźliby był człowiekiem Galilejskim?
7 Nígbà tí ó sì mọ̀ pé ará ilẹ̀ abẹ́ àṣẹ Herodu ni, ó rán an sí Herodu, ẹni tí òun tìkára rẹ̀ wà ní Jerusalẹmu ní àkókò náà.
A gdy się dowiedział, iż był z państwa Herodowego, odesłał go do Heroda, który też w Jeruzalemie był w one dni.
8 Nígbà tí Herodu, sì rí Jesu, ó yọ̀ gidigidi; nítorí tí ó ti ń fẹ́ rí i pẹ́ ó sá à ti ń gbọ́ ìròyìn púpọ̀ nítorí rẹ̀; ó sì ń retí láti rí i kí iṣẹ́ àmì díẹ̀ ti ọwọ́ rẹ̀ ṣe.
A Herod ujrzawszy Jezusa, uradował się bardzo; bo go z dawna pragnął widzieć, dlatego, iż wiele o nim słyszał, i spodziewał się, iż miał ujrzeć jaki cud od niego uczyniony.
9 Ó sì béèrè ọ̀rọ̀ púpọ̀ lọ́wọ́ rẹ̀; ṣùgbọ́n kò da a lóhùn rárá.
I pytał go wielą słów; ale mu on nic nie odpowiadał.
10 Àti àwọn olórí àlùfáà àti àwọn akọ̀wé dúró, wọ́n sì ń fi ẹ̀sùn kàn án gidigidi.
A przedniejsi kapłani i nauczeni w Piśmie stali, potężnie skarżąc nań.
11 Àti Herodu pẹ̀lú àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, wọ́n kẹ́gàn rẹ̀, wọ́n sì ń fi í ṣẹ̀sín, wọ́n wọ̀ ọ́ ní aṣọ dáradára, ó sì rán an padà tọ Pilatu lọ.
Ale wzgardziwszy nim Herod z żołnierstwem swem i naśmiawszy się z niego, oblekł go w szatę białą i odesłał go zaś do Piłata.
12 Pilatu àti Herodu di ọ̀rẹ́ ara wọn ní ọjọ́ náà, nítorí látijọ́ ọ̀tá ara wọn ni wọ́n ti jẹ́ rí.
I stali się sobie przyjaciołmi Piłat z Herodem onegoż to dnia; bo sobie byli przedtem nieprzyjaciołmi.
13 Pilatu sì pe àwọn olórí àlùfáà àti àwọn olórí àti àwọn ènìyàn jọ.
A Piłat zwoławszy przedniejszych kapłanów i przełożonych, i ludu,
14 Ó sọ fún wọn pé, “Ẹyin mú ọkùnrin yìí tọ̀ mí wá, bí ẹni tí ó ń yí àwọn ènìyàn ní ọkàn padà. Sì kíyèsi i, èmí wádìí ẹjọ́ rẹ̀ níwájú yín èmi kò sì rí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ kan lọ́wọ́ ọkùnrin yìí, ní gbogbo nǹkan wọ̀nyí tí ẹ̀yin fi ẹ̀sùn rẹ̀ sùn.
Rzekł do nich: Oddaliście mi tego człowieka, jakoby lud odwracał: a oto ja przed wami pytając go, żadnej winy nie znalazłem w tym człowieku z tego, co nań skarżycie;
15 Àti Herodu pẹ̀lú; ó sá rán an padà tọ̀ wá wá; sì kíyèsi i, ohun kan tí ó yẹ sí ikú ni a kò ṣe láti ọwọ́ rẹ̀.
Ale ani Herod, bom was odesłał do niego, a oto nic mu się godnego śmierci nie stało;
16 Ǹjẹ́ èmi ó nà án, èmi ó sì fi í sílẹ̀ lọ.”
Przetoż skarawszy wypuszczę go.
A musiał im Piłat wypuszczać jednego na święto.
18 Wọ́n sì kígbe sókè nígbà kan náà, pé, “Mú ọkùnrin yìí kúrò, kí o sì dá Baraba sílẹ̀ fún wa!”
Tedy zawołało społem wszystko mnóstwo, mówiąc: Strać tego a wypuść nam Barabbasza!
19 Ẹni tí a sọ sínú túbú nítorí ọ̀tẹ̀ kan tí a ṣe ní ìlú, àti nítorí ìpànìyàn.
Który był dla niejakiego rozruchu w mieście uczynionego, i dla mężobójstwa wsadzony do więzienia.
20 Pilatu sì tún bá wọn sọ̀rọ̀, nítorí ó fẹ́ dá Jesu sílẹ̀.
Tedy Piłat znowu mówił, chcąc wypuścić Jezusa.
21 Ṣùgbọ́n wọ́n kígbe, wí pé, “Kàn án mọ́ àgbélébùú, kàn án mọ àgbélébùú!”
Ale oni przecię wołali, mówiąc: Ukrzyżuj, ukrzyżuj go!
22 Ó sì wí fún wọn lẹ́ẹ̀mẹ́ta pé, “Èéṣe, búburú kín ni ọkùnrin yìí ṣe? Èmi kò rí ọ̀ràn ikú lára rẹ̀: nítorí náà èmi ó nà án, èmi ó sì fi í sílẹ̀.”
A on po trzecie rzekł do nich: I cóż wżdy ten złego uczynił? Żadnej winy śmierci nie znalazłem w nim; przetoż skarawszy wypuszczę go.
23 Wọ́n túbọ̀ tẹramọ́ igbe ńlá, wọ́n ń fẹ́ kí a kàn án mọ́ àgbélébùú, ohùn tiwọn àti ti àwọn olórí àlùfáà borí tirẹ̀.
A oni przecię nalegali głosy wielkimi, żądając, aby był ukrzyżowany; i zmacniały się głosy ich i przedniejszych kapłanów.
24 Pilatu sí fi àṣẹ sí i pé, kí ó rí bí wọ́n ti ń fẹ́.
A tak Piłat przysądził, aby się dosyć stało żądności ich.
25 Ó sì dá ẹni tí wọ́n fẹ́ sílẹ̀ fún wọn, ẹni tí a tìtorí ọ̀tẹ̀ àti ìpànìyàn sọ sínú túbú; ṣùgbọ́n ó fi Jesu lé wọn lọ́wọ́.
I wypuścił im onego, który był dla rozruchu i mężobójstwa wsadzony do więzienia, o którego prosili; ale Jezusa podał na wolę ich.
26 Bí wọ́n sì ti ń fà á lọ, wọ́n mú ọkùnrin kan, Simoni ara Kirene, tí ó ń ti ìgbèríko bọ̀, òun ni wọ́n sì gbé àgbélébùú náà lé, kí ó máa rù ú lọ tẹ̀lé Jesu.
Gdy go tedy wiedli, uchwyciwszy Szymona niektórego Cyrenejczyka, idącego z pola, włożyli nań krzyż, aby go niósł za Jezusem.
27 Ìjọ ènìyàn púpọ̀ ni ó ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, àti àwọn obìnrin, tí ń pohùnréré ẹkún,
I szło za nim wielkie mnóstwo ludu i niewiast, które go płakały i narzekały.
28 ṣùgbọ́n Jesu yíjú padà sí wọn, ó sì wí pé, “Ẹ̀yin ọmọbìnrin Jerusalẹmu, ẹ má sọkún fún mi, ṣùgbọ́n ẹ sọkún fún ara yín, àti fún àwọn ọmọ yín.
Ale Jezus obróciwszy się do nich, rzekł: Córki Jeruzalemskie! nie płaczcie nade mną, ale raczej same nad sobą płaczcie i nad dziatkami waszemi.
29 Nítorí kíyèsi i, ọjọ́ ń bọ̀ ní èyí tí ẹ̀yin ó wí pé, ‘Ìbùkún ni fún àgàn, àti fún inú tí kò bímọ rí, àti fún ọmú tí kò fún ni mu rí!’
Albowiemci oto idą dni, których będą mówić: Błogosławione niepłodne i żywoty, które nie rodziły, i piersi, które nie karmiły.
30 Nígbà náà ni “‘wọn ó bẹ̀rẹ̀ sí wí fún àwọn òkè kéékèèké pé, “Yí lù wá!” Sí àwọn òkè ńlá, “Bò wá mọ́lẹ̀!”’
Tedy poczną mówić górom: Padnijcie na nas! a pagórkom: Przykryjcie nas!
31 Nítorí bí wọn bá ń ṣe nǹkan wọ̀nyí sára igi tútù, kín ni a ó ṣe sára igi gbígbẹ?”
Albowiem ponieważ się to na zielonem drzewie dzieje, a cóż będzie na suchem?
32 Àwọn méjì mìíràn bákan náà, àwọn arúfin, ni wọ́n sì fà lọ pẹ̀lú rẹ̀ láti pa.
Wiedzieni też byli i inni dwaj złoczyńcy, aby wespół z nim straceni byli.
33 Nígbà tí wọ́n sì dé ibi tí a ń pè ní Agbárí, níbẹ̀ ni wọ́n gbé kàn án mọ́ àgbélébùú, àti àwọn arúfin náà, ọ̀kan ní ọwọ́ ọ̀tún, àti ọ̀kan ní ọwọ́ òsì.
A gdy przyszli na miejsce, które zowią trupich głów, tam go ukrzyżowali, i onych złoczyńców, jednego po prawicy, a drugiego po lewicy.
34 Jesu sì wí pé, “Baba, dáríjì wọ́n; nítorí tí wọn kò mọ ohun tí wọ́n ń ṣe.” Wọ́n di ìbò láti pín aṣọ rẹ̀ láàrín ara wọn.
Tedy Jezus rzekł: Ojcze! odpuść im: boć nie wiedzą, co czynią. A rozdzieliwszy szaty jego, los o nie miotali.
35 Àwọn ènìyàn sì dúró láti wòran. Àti àwọn ìjòyè pẹ̀lú wọn, wọ́n ń yọ ṣùtì sí i, wí pé, “Ó gba àwọn ẹlòmíràn là; kí ó gbara rẹ̀ là, bí ó bá ṣe Kristi, àyànfẹ́ Ọlọ́run.”
I stał lud, przypatrując się, a naśmiewali się z niego i przełożeni z nimi, mówiąc: Inszych ratował, niechże ratuje samego siebie, jeźliże on jest Chrystus, on wybrany Boży.
36 Àti àwọn ọmọ-ogun pẹ̀lú ń fi í ṣe ẹlẹ́yà, wọ́n tọ̀ ọ́ wá, wọ́n ń fi ọtí kíkan fún un.
Naśmiewali się też z niego i żołnierze, przystępując, a ocet mu podawając,
37 Wọ́n sì ń wí pé, “Bí ìwọ bá ṣe ọba àwọn Júù, gba ara rẹ là.”
I mówiąc: Jeźliś ty jest król żydowski, ratujże samego siebie.
38 Wọ́n sì kọ̀wé àkọlé sí ìgbèrí rẹ̀ ní èdè Giriki, àti ti Latin, àti tí Heberu pe: Èyí ni Ọba àwọn Júù.
A był też i napis napisany nad nim literami Greckiemi i Łacińskiemi i Żydowskiemi: Tenci jest on król żydowski.
39 Àti ọ̀kan nínú àwọn arúfin tí a gbé kọ́ ń fi ṣe ẹlẹ́yà wí pé, “Bí ìwọ bá ṣe Kristi, gba ara rẹ àti àwa náà là.”
A jeden z onych złoczyńców, którzy z nim wisieli, urągał mu, mówiąc: Jeźliżeś ty jest Chrystus, ratujże siebie i nas.
40 Ṣùgbọ́n èyí èkejì dáhùn, ó ń bá a wí pé, “Ìwọ kò bẹ̀rù Ọlọ́run, tí ìwọ wà nínú ẹ̀bi kan náà?
A odpowiadając drugi, gromił go mówiąc: I ty się Boga nie boisz, chociażeś jest w temże skazaniu?
41 Ní tiwa, wọ́n jàre nítorí èrè ohun tí àwa ṣe ni à ń jẹ, ṣùgbọ́n ọkùnrin yìí kò ṣe ohun búburú kan.”
A myć zaiste sprawiedliwie; (bo godną zapłatę za uczynki nasze bierzemy; ) ale ten nic złego nie uczynił.
42 Ó sì wí pé, “Jesu, rántí mi nígbà tí ìwọ bá dé ìjọba rẹ.”
I rzekł do Jezusa: Panie! pomnij na mnie, gdy przyjdziesz do królestwa twego.
43 Jesu sì wí fún un pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún ọ, lónìí ni ìwọ ó wà pẹ̀lú mi ní Paradise!”
A Jezus mu rzekł: Zaprawdę powiadam tobie, dziś ze mną będziesz w raju.
44 Ó sì tó ìwọ̀n wákàtí kẹfà ọjọ́, òkùnkùn sì ṣú bo gbogbo ilẹ̀ títí ó fi di wákàtí kẹsànán ọjọ́.
A było około szóstej godziny, i stała się ciemność po wszystkiej ziemi aż do godziny dziewiątej.
45 Òòrùn sì ṣú òòkùn, aṣọ ìkélé ti tẹmpili sì ya ní àárín méjì.
I zaćmiło się słońce, a zasłona kościelna rozerwała się w pół.
46 Nígbà tí Jesu sì kígbe lóhùn rara, ó ní, “Baba, ní ọwọ́ rẹ ni mo fi ẹ̀mí mi lé!” Nígbà tí ó sì wí èyí tan, ó jọ̀wọ́ ẹ̀mí rẹ̀.
A Jezus zawoławszy głosem wielkim, rzekł: Ojcze! w ręce twoje polecam ducha mojego; a to rzekłszy, skonał.
47 Nígbà tí balógun ọ̀rún rí ohun tí ó ṣe, ó yin Ọlọ́run lógo, wí pé, “Dájúdájú olódodo ni ọkùnrin yìí!”
A widząc setnik, co się działo, chwalił Boga, mówiąc: Zaprawdę człowiek to był sprawiedliwy.
48 Gbogbo ìjọ ènìyàn tí ó péjọ láti rí ìran yìí, nígbà tí wọ́n rí ohun tí ó ṣẹlẹ̀ wọ́n lu ara wọn ní oókan àyà, wọ́n sì padà sí ilé.
Także i wszystek lud, który się był zszedł na to dziwowisko, widząc, co się działo, bijąc się w piersi swoje, wracał się.
49 Àti gbogbo àwọn ojúlùmọ̀ rẹ̀, àti àwọn obìnrin tí ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn láti Galili wá, wọ́n dúró lókèèrè, wọ́n ń wo nǹkan wọ̀nyí.
A znajomi jego wszyscy z daleka stali, i niewiasty, które za nim były przyszły z Galilei, przypatrując się temu.
50 Sì kíyèsi i, ọkùnrin kan tí a ń pè ní Josẹfu, láti ìlú àwọn Júù kan tí ń jẹ́ Arimatea. Ó jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ọmọ ìgbìmọ̀, ènìyàn rere, àti olóòtítọ́.
A oto mąż, imieniem Józef, który był senatorem, mąż dobry i sprawiedliwy,
51 Òun kò bá wọn fi ohùn sí ìmọ̀ àti ìṣe wọn; Ó wá láti Judea, ìlú àwọn ará Arimatea, òun pẹ̀lú ń retí ìjọba Ọlọ́run.
Który był nie zezwolił na radę i na uczynek ich, z Arymatyi, miasta Judzkiego, który też oczekiwał królestwa Bożego;
52 Ọkùnrin yìí tọ Pilatu lọ, ó sì tọrọ òkú Jesu.
Ten przyszedłszy do Piłata, prosił o ciało Jezusowe.
53 Nígbà tí ó sì sọ̀ ọ́ kalẹ̀, ó sì fi aṣọ àlà dì í, ó sì tẹ́ ẹ sínú ibojì tí a gbẹ́ nínú Òkúta, níbi tí a kò tẹ́ ẹnikẹ́ni sí rí.
I zdjąwszy je, obwinął je prześcieradłem a położył je w grobie w opoce wykowanym, w którym jeszcze nikt nigdy nie był położony.
54 Ó sì jẹ́ ọjọ́ ìpalẹ̀mọ́, ọjọ́ ìsinmi sì kù sí dẹ̀dẹ̀.
A był dzień przygotowania, i sabat nastawał.
55 Àti àwọn obìnrin, tí wọ́n bá a ti Galili wá, tí wọ́n sì tẹ̀lé, wọ́n kíyèsi ibojì náà, àti bí a ti tẹ́ òkú rẹ̀ sílẹ̀.
Poszedłszy też za nim i niewiasty, które były z nim przyszły z Galilei, oglądały grób, i jako było położone ciało jego.
56 Nígbà tí wọ́n sì padà, wọ́n pèsè ohun olóòórùn dídùn, òróró ìkunra (àti tùràrí tútù); wọ́n sì sinmi ní ọjọ́ ìsinmi gẹ́gẹ́ bí òfin.
A wróciwszy się, nagotowały wonnych rzeczy i maści; ale w sabat odpoczęły według przykazania.

< Luke 23 >