< Luke 23 >

1 Gbogbo ìjọ ènìyàn sì dìde, wọ́n sì fà á lọ sí ọ̀dọ̀ Pilatu.
ⲁ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁϥⲧⲱⲛϥ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲟⲩⲙⲏϣ ⲧⲏⲣϥ ⲁⲩ⳿ⲉⲛϥ ϩⲁ ⲡⲓⲗⲁⲧⲟⲥ.
2 Wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí fi ẹ̀sùn kàn án, wí pé, “Àwa rí ọkùnrin yìí ó ń yí orílẹ̀-èdè wa lọ́kàn padà, ó sì ń dá wọn lẹ́kun láti san owó òde fún Kesari, ó ń wí pé, òun tìkára òun ni Kristi ọba.”
ⲃ̅ⲩⲉⲣϩⲏⲧⲥ ⲇⲉ ⳿ⲛⲉⲣⲕⲁⲧⲏⲅⲟⲣⲓⲛ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⲉⲩϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲫⲁⲓ ⲁⲛϫⲉⲙϥ ⲉⲧⲫⲱⲛϩ ⳿ⲙⲡⲉⲛⲉⲑⲛⲟⲥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲟⲩⲟϩ ⲉϥⲧⲁϩⲛⲟ ⳿ⲉ⳿ϣⲧⲉⲙϯ ϩⲱϯ ⲙ⳿ⲡⲟⲩⲣⲟ ⲉϥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⳿ⲉⲣⲟϥ ϫⲉ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲡⲉ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ⳿ⲡⲟⲩⲣⲟ.
3 Pilatu sì bi í léèrè, wí pé, “Ìwọ ha ni ọba àwọn Júù?” Ó sì dá a lóhùn wí pé, “Ìwọ wí i.”
ⲅ̅ⲡⲓⲗⲁⲧⲟⲥ ⲇⲉ ⲁϥϣⲉⲛϥ ⲉϥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⳿ⲛⲑⲟⲕ ⲡⲉ ⳿ⲡⲟⲩⲣⲟ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓⲓⲟⲩⲇⲁⲓ ⲛⲑⲟϥ ⲇⲉ ⲁϥⲉⲣⲟⲩⲱ ⲛⲁϥ ϫⲉ ⳿ⲛⲑⲟⲕ ⲡⲉⲧϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ.
4 Pilatu sì wí fún àwọn olórí àlùfáà àti fún ìjọ ènìyàn pé, “Èmi kò rí ẹ̀ṣẹ̀ lọ́wọ́ ọkùnrin yìí.”
ⲇ̅ⲡⲓⲗⲁⲧⲟⲥ ⲇⲉ ⲡⲉϫⲁϥ ⳿ⲛⲛⲓⲁⲣⲭⲓⲉⲣⲉⲩⲥ ⲛⲉⲙ ⲛⲓⲙⲏϣ ϫⲉ ⳿ⲛϯϫⲉⲙ ⳿ϩⲗⲓ ⳿ⲛⲉⲧⲓ⳿ⲁ ⲁⲛ ϧⲉⲛ ⲡⲁⲓⲣⲱⲙⲓ.
5 Wọ́n sì túbọ̀ tẹnumọ́ ọn pé, “Ó ń ru ènìyàn sókè, ó ń kọ́ni káàkiri gbogbo Judea, ó bẹ̀rẹ̀ láti Galili títí ó fi dé ìhín yìí!”
ⲉ̅⳿ⲛⲑⲱⲟⲩ ⲇⲉ ⲛⲁⲩϫⲉⲙϫⲟⲙ ⲉⲩϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⳿ϥ⳿ϣⲑⲟⲣⲧⲉⲣ ⳿ⲙⲡⲓⲗⲁⲟⲥ ⲉϥϯ⳿ⲥⲃⲱ ϧⲉⲛ ϯⲓⲟⲩⲇⲉ⳿ⲁ ⲧⲏⲣⲥ ⳿ⲉⲁϥⲉⲣϩⲏⲧⲥ ⲥϫⲉⲛ ⲅⲁⲗⲓⲗⲉ⳿ⲁ ϣⲁ ⲡⲁⲓⲙⲁ.
6 Nígbà tí Pilatu gbọ́ orúkọ Galili, ó béèrè bí ọkùnrin náà bá jẹ́ ará Galili.
ⲋ̅ⲡⲓⲗⲁⲧⲟⲥ ⲇⲉ ⲉⲧⲁϥⲥⲱⲧⲉⲙ ⲛⲁϥϣⲓⲛⲓ ϫⲉ ⲁⲛ ⲟⲩⲅⲁⲗⲓⲗⲉⲟⲥ ⲡⲉ ⲡⲁⲓⲣⲱⲙⲓ.
7 Nígbà tí ó sì mọ̀ pé ará ilẹ̀ abẹ́ àṣẹ Herodu ni, ó rán an sí Herodu, ẹni tí òun tìkára rẹ̀ wà ní Jerusalẹmu ní àkókò náà.
ⲍ̅ⲟⲩⲟϩ ⲉⲧⲁϥ⳿ⲉⲙⲓ ϫⲉ ⲩ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⳿ⲡⲉⲣϣⲓϣⲓ ⳿ⲛⲏⲣⲱⲇⲏⲥ ⲡⲉ ⲁϥⲟⲩⲟⲣⲡϥ ϩⲁ ⲏⲣⲱⲇⲏⲥ ⲉϥⲭⲏ ϩⲱϥ ϧⲉⲛ ⳿ⲓⲗ̅ⲏ̅ⲙ̅ ϧⲉⲛ ⲛⲓ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲁⲩ.
8 Nígbà tí Herodu, sì rí Jesu, ó yọ̀ gidigidi; nítorí tí ó ti ń fẹ́ rí i pẹ́ ó sá à ti ń gbọ́ ìròyìn púpọ̀ nítorí rẹ̀; ó sì ń retí láti rí i kí iṣẹ́ àmì díẹ̀ ti ọwọ́ rẹ̀ ṣe.
ⲏ̅ⲏⲣⲱⲇⲏⲥ ⲇⲉ ⲧⲁϥⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲒⲏ̅ⲥ̅ ⲁϥⲣⲁϣⲓ ⳿ⲉⲙⲁϣⲱ ⲛⲁϥⲟⲩⲱϣ ⲅⲁⲣ ⲡⲉ ⳿ⲉⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⲓⲥϫⲉⲛ ⲟⲩⲙⲏϣ ⳿ⲛ⳿ⲭⲣⲟⲛⲟⲥ ⲉⲑⲃⲉϫⲉ ⲛⲁϥⲥⲱⲧⲉⲙ ⲉⲑⲃⲏⲧϥ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥⲉⲣϩⲉⲗⲡⲓⲥ ⳿ⲉⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲟⲩⲙⲏⲓⲛⲓ ⳿ⲛⲧⲟⲧϥ ⲉϥ⳿ⲓⲣⲓ ⳿ⲙⲙⲟϥ.
9 Ó sì béèrè ọ̀rọ̀ púpọ̀ lọ́wọ́ rẹ̀; ṣùgbọ́n kò da a lóhùn rárá.
ⲑ̅ⲛⲁϥϣⲓⲛⲓ ⲇⲉ ⳿ⲙⲙⲟϥ ϧⲉⲛ ϩⲁⲛⲙⲏϣ ⳿ⲛⲥⲁϫⲓ ⳿ⲛⲑⲟϥ ⲇⲉ ⳿ⲙⲡⲉⲣⲉⲣⲟⲩⲱ ⳿ⲛ⳿ϩⲗⲓ.
10 Àti àwọn olórí àlùfáà àti àwọn akọ̀wé dúró, wọ́n sì ń fi ẹ̀sùn kàn án gidigidi.
ⲓ̅ⲛⲁⲩⲟϩⲓ ⳿ⲉⲣⲁⲧⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲓⲁⲣⲭⲓⲉⲣⲉⲩⲥ ⲛⲉⲙ ⲛⲓⲥⲁϧ ⲉⲩⲉⲣⲕⲁⲧⲏⲅⲟⲣⲓⲛ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⳿ⲉⲙⲁϣⲱ.
11 Àti Herodu pẹ̀lú àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, wọ́n kẹ́gàn rẹ̀, wọ́n sì ń fi í ṣẹ̀sín, wọ́n wọ̀ ọ́ ní aṣọ dáradára, ó sì rán an padà tọ Pilatu lọ.
ⲓ̅ⲁ̅ⲉⲧⲁϥϣⲟϣϥ ⲇⲉ ⳿ⲛϫⲉ ⲏⲣⲱⲇⲏⲥ ⲛⲉⲙ ⲛⲉϥⲙⲁⲧⲟⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲧⲁϥⲥⲱⲃⲓ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲁϥϫⲟⲗϩϥ ⳿ⲛⲟⲩϩⲉⲃⲥⲱ ⲉⲥⲫⲉⲣⲓⲱⲟⲩ ⲁϥⲟⲩⲟⲣⲡϥ ⳿ⲉⲡⲓⲗⲁⲧⲟⲥ.
12 Pilatu àti Herodu di ọ̀rẹ́ ara wọn ní ọjọ́ náà, nítorí látijọ́ ọ̀tá ara wọn ni wọ́n ti jẹ́ rí.
ⲓ̅ⲃ̅ⲁⲩⲉⲣ⳿ϣⲫⲏⲣ ⲇⲉ ⳿ⲉⲛⲟⲩⲉⲣⲏⲟⲩ ⲛϫⲉ ⲡⲓⲗⲁⲧⲟⲥ ⲛⲉⲙ ⲏⲣⲱⲇⲏⲥ ϧⲉⲛ ⲡⲓ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲛⲁⲩϣⲟⲡ ⲅⲁⲣ ⳿ⲛϣⲟⲣⲡ ⲡⲉ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲙⲉⲧϫⲁϫⲓ ⳿ⲉⲛⲟⲩⲉⲣⲏⲟⲩ.
13 Pilatu sì pe àwọn olórí àlùfáà àti àwọn olórí àti àwọn ènìyàn jọ.
ⲓ̅ⲅ̅ⲡⲓⲗⲁⲧⲟⲥ ⲇⲉ ⲧⲁϥⲙⲟⲩϯ ⳿ⲉⲛⲓⲁⲣⲭⲓⲉⲣⲉⲩⲥ ⲛⲉⲙ ⲛⲓⲁⲣⲭⲱⲛ ⲛⲉⲙ ⲡⲓⲗⲁⲟⲥ.
14 Ó sọ fún wọn pé, “Ẹyin mú ọkùnrin yìí tọ̀ mí wá, bí ẹni tí ó ń yí àwọn ènìyàn ní ọkàn padà. Sì kíyèsi i, èmí wádìí ẹjọ́ rẹ̀ níwájú yín èmi kò sì rí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ kan lọ́wọ́ ọkùnrin yìí, ní gbogbo nǹkan wọ̀nyí tí ẹ̀yin fi ẹ̀sùn rẹ̀ sùn.
ⲓ̅ⲇ̅ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ⲁⲧⲉⲧⲉⲛ⳿ⲓⲛⲓ ⲛⲏⲓ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲣⲱⲙⲓ ϩⲱⲥ ⲉϥⲫⲱⲛϩ ⳿ⲙⲡⲓⲗⲁⲟⲥ ⲉⲃⲟⲗ ⲟⲩⲟϩ ϩⲏⲡⲡⲉ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲉⲧⲁⲓϣⲉⲛϥ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲁϥ ⳿ⲙⲡⲉⲧⲉⲛ⳿ⲙⲑⲟ ⳿ⲙⲡⲓϫⲉⲙ ⳿ϩⲗⲓ ⳿ⲛⲉⲧⲓ⳿ⲁ ϧⲉⲛ ⲡⲁⲓⲣⲱⲙⲓ ⳿ⲛⲛⲏⲉⲧⲉⲧⲉⲛⲉⲣⲕⲁⲧⲏⲅⲟⲣⲓⲛ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⳿ⲛϧⲏⲧⲟⲩ.
15 Àti Herodu pẹ̀lú; ó sá rán an padà tọ̀ wá wá; sì kíyèsi i, ohun kan tí ó yẹ sí ikú ni a kò ṣe láti ọwọ́ rẹ̀.
ⲓ̅ⲉ̅ⲁⲗⲗⲁ ⲟⲩⲇⲉ ⳿ⲡⲕⲉⲏⲣⲱⲇⲏⲥ ⲁϥⲟⲩⲟⲣⲡϥ ⲅⲁⲣ ϩⲁⲣⲟⲛ ⲟⲩⲟϩ ϩⲏⲡⲡⲉ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⳿ϩⲗⲓ ⳿ⲛϩⲱⲃ ⳿ⲛϧⲏⲧϥ ⳿ⲉⲁϥⲁⲓϥ ⲉϥ⳿ⲙ⳿ⲡϣⲁ ⳿ⲙ⳿ⲫⲙⲟⲩ.
16 Ǹjẹ́ èmi ó nà án, èmi ó sì fi í sílẹ̀ lọ.”
ⲓ̅ⲋ̅⳿ⲛⲧⲁϯ⳿ⲥⲃⲱ ⲟⲩⲛ ⲛⲁϥ ⳿ⲛⲧⲁⲭⲁϥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ.
ⲓ̅ⲍ̅ⲛⲉ ⲟⲩⲟⲛⲧⲟⲩ ⲕⲁϩⲥ ⲇⲉ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲉⲑⲣⲉϥⲭⲱ ⳿ⲛⲟⲩⲁⲓ ⳿ⲛⲛⲏⲉⲧⲥⲟⲛϩ ⲛⲱⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲁⲧⲁ ⳿ⲡϣⲁⲓ.
18 Wọ́n sì kígbe sókè nígbà kan náà, pé, “Mú ọkùnrin yìí kúrò, kí o sì dá Baraba sílẹ̀ fún wa!”
ⲓ̅ⲏ̅ⲁ ⲡⲓⲙⲏϣ ⲇⲉ ⲧⲏⲣϥ ⲱϣ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϫⲉ ⲁⲗⲓ ⲫⲁⲓ ⲭⲁ ⲃⲁⲣⲁⲃⲃⲁⲥ ⲛⲁⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗ.
19 Ẹni tí a sọ sínú túbú nítorí ọ̀tẹ̀ kan tí a ṣe ní ìlú, àti nítorí ìpànìyàn.
ⲓ̅ⲑ̅ⲫⲁⲓ ⲉⲧⲁⲩϩⲓⲧϥ ⳿ⲉ⳿ⲡ⳿ϣⲧⲉⲕⲟ ⲉⲑⲃⲉ ⲟⲩ⳿ϣⲑⲟⲣⲧⲉⲣ ⲛⲉⲙ ⲟⲩϧⲱⲧⲉⲃ ⳿ⲉⲁϥϣⲱⲡⲓ ϧⲉⲛ ϯⲡⲟⲗⲓⲥ.
20 Pilatu sì tún bá wọn sọ̀rọ̀, nítorí ó fẹ́ dá Jesu sílẹ̀.
ⲕ̅ⲡⲁⲗⲓⲛ ⲇⲉ ⲟⲛ ⲁ ⲡⲓⲗⲁⲧⲟⲥ ⲙⲟⲩϯ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ ⲉϥⲟⲩⲱϣ ⳿ⲉⲭⲁ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⳿ⲉⲃⲟⲗ.
21 Ṣùgbọ́n wọ́n kígbe, wí pé, “Kàn án mọ́ àgbélébùú, kàn án mọ àgbélébùú!”
ⲕ̅ⲁ̅⳿ⲛⲑⲱⲟⲩ ⲇⲉ ⲁⲩⲱϣ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲉⲩϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲁϣϥ ⲁϣϥ.
22 Ó sì wí fún wọn lẹ́ẹ̀mẹ́ta pé, “Èéṣe, búburú kín ni ọkùnrin yìí ṣe? Èmi kò rí ọ̀ràn ikú lára rẹ̀: nítorí náà èmi ó nà án, èmi ó sì fi í sílẹ̀.”
ⲕ̅ⲃ̅⳿ⲛⲑⲟϥ ⲇⲉ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲱⲟⲩ ⳿ⲙ⳿ⲫⲙⲁϩⲅ̅ ⳿ⲛⲥⲟⲡ ϫⲉ ⲟⲩ ⲅⲁⲣ ⲙⲡⲉⲧϩⲱⲟⲩ ⲡⲉⲧⲁ ⲫⲁⲓ ⲁⲓϥ ⳿ⲙⲡⲓϫⲉⲙ ⳿ϩⲗⲓ ⳿ⲛⲉⲧⲓ⳿ⲁ ⳿ⲛⲧⲉ ⳿ⲫⲙⲟⲩ ⳿ⲛϧⲏⲧϥ ⳿ⲛⲧⲁϯ⳿ⲥⲃⲱ ⲟⲩⲛ ⲛⲁϥ ⳿ⲛⲧⲁⲭⲁϥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ.
23 Wọ́n túbọ̀ tẹramọ́ igbe ńlá, wọ́n ń fẹ́ kí a kàn án mọ́ àgbélébùú, ohùn tiwọn àti ti àwọn olórí àlùfáà borí tirẹ̀.
ⲕ̅ⲅ̅⳿ⲛⲑⲱⲟⲩ ⲇⲉ ⲩⲟⲩⲁϩⲧⲟⲧⲟⲩ ϧⲉⲛ ϩⲁⲛⲛⲓϣϯ ⳿ⲛ⳿ⲥⲙⲏ ⲉⲩⲉⲣⲉⲧⲓⲛ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲉⲑⲣⲟⲩⲁϣϥ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁⲩϫⲉⲙϫⲟⲙ ⲡⲉ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲟⲩ⳿ⲥⲙⲏ.
24 Pilatu sí fi àṣẹ sí i pé, kí ó rí bí wọ́n ti ń fẹ́.
ⲕ̅ⲇ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁ ⲡⲓⲗⲁⲧⲟⲥ ϩⲁⲡ ⲉⲑⲣⲉϥϣⲱⲡⲓ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲟⲩⲉⲧⲏⲙⲁ.
25 Ó sì dá ẹni tí wọ́n fẹ́ sílẹ̀ fún wọn, ẹni tí a tìtorí ọ̀tẹ̀ àti ìpànìyàn sọ sínú túbú; ṣùgbọ́n ó fi Jesu lé wọn lọ́wọ́.
ⲕ̅ⲉ̅ⲁϥⲭⲱ ⲇⲉ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲙⲫⲏⲉⲧⲁⲩϩⲓⲧϥ ⳿ⲉ⳿ⲡ⳿ϣⲧⲉⲕⲟ ⲉⲑⲃⲉ ⲟⲩϧⲱⲧⲉⲃ ⲛⲉⲙ ⳿ϣⲑⲟⲣⲧⲉⲣ ⲫⲏ ⲧⲁⲩⲉⲣⲉⲧⲓⲛ ⳿ⲙⲙⲟϥ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲇⲉ ⲁϥⲧⲏⲓϥ ⲕⲁⲧⲁ ⲡⲟⲩⲟⲩⲱϣ.
26 Bí wọ́n sì ti ń fà á lọ, wọ́n mú ọkùnrin kan, Simoni ara Kirene, tí ó ń ti ìgbèríko bọ̀, òun ni wọ́n sì gbé àgbélébùú náà lé, kí ó máa rù ú lọ tẹ̀lé Jesu.
ⲕ̅ⲋ̅ⲟⲩⲟϩ ϩⲱⲥ ⲉⲩ⳿ⲓⲛⲓ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲁⲩ⳿ⲁⲙⲟⲛⲓ ⳿ⲛⲟⲩⲁⲓ ϫⲉ ⲥⲓⲙⲱⲛ ⲟⲩⲕⲩⲣⲓⲛⲉⲟⲥ ϥⲛⲏ ⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⳿ⲧⲕⲟⲓ ⲁⲩⲧⲁⲗⲉ ⲡⲓ⳿ⲥⲧⲁⲩⲣⲟⲥ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⲉⲑⲣⲉϥⲧⲱⲟⲩⲛ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲥⲁⲫⲁϩⲟⲩ ⳿ⲙⲙⲟϥ.
27 Ìjọ ènìyàn púpọ̀ ni ó ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, àti àwọn obìnrin, tí ń pohùnréré ẹkún,
ⲕ̅ⲍ̅ⲛⲁϥⲙⲟϣⲓ ⲇⲉ ⳿ⲛⲥⲱϥ ⳿ⲛϫⲉ ⲟⲩⲛⲓϣϯ ⳿ⲙⲙⲏϣ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓⲗⲁⲟⲥ ⲛⲉⲙ ϩⲁⲛϩⲓ⳿ⲟⲙⲓ ⲛⲏ⳿ⲉⲛⲁⲩⲧⲱⲓⲧ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁⲩⲛⲉϩⲡⲓ ⳿ⲉⲣⲟϥ.
28 ṣùgbọ́n Jesu yíjú padà sí wọn, ó sì wí pé, “Ẹ̀yin ọmọbìnrin Jerusalẹmu, ẹ má sọkún fún mi, ṣùgbọ́n ẹ sọkún fún ara yín, àti fún àwọn ọmọ yín.
ⲕ̅ⲏ̅⳿ⲉⲧⲁϥⲫⲟⲛϥ ⲇⲉ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲡⲉϫⲁϥ ϫⲉ ⲛⲓϣⲉⲣⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲓⲗ̅ⲏ̅ⲙ̅ ⳿ⲙⲡⲉⲣⲣⲓⲙⲓ ⳿ⲉϫⲱⲓ ⳿ⲡⲗⲏⲛ ⲣⲓⲙⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲛⲉⲙ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲛⲉⲧⲉⲛϣⲏⲣⲓ.
29 Nítorí kíyèsi i, ọjọ́ ń bọ̀ ní èyí tí ẹ̀yin ó wí pé, ‘Ìbùkún ni fún àgàn, àti fún inú tí kò bímọ rí, àti fún ọmú tí kò fún ni mu rí!’
ⲕ̅ⲑ̅ϫⲉ ϩⲏⲡⲡⲉ ⲥⲉⲛⲏⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ ϩⲁⲛ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⲛⲏ ⲧⲟⲩⲛⲁϫⲟⲥ ⳿ⲛϧⲏⲧⲟⲩ ϫⲉ ⲱⲟⲩ⳿ⲛⲓⲁⲧⲟⲩ ⳿ⲛⲛⲓⲁⲧϭ ⲣⲏⲛ ⲛⲉⲙ ⲛⲓⲛⲉϫⲓ ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲡⲟⲩⲙⲓⲥⲓ ⲛⲉⲙ ⲛⲓⲉⲙⲛⲟϯ ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲡⲟⲩϣⲁⲛϣ.
30 Nígbà náà ni “‘wọn ó bẹ̀rẹ̀ sí wí fún àwọn òkè kéékèèké pé, “Yí lù wá!” Sí àwọn òkè ńlá, “Bò wá mọ́lẹ̀!”’
ⲗ̅ⲧⲟⲧⲉ ⲉⲛⲁⲉⲣϩⲏⲧⲥ ⳿ⲛϫⲟⲥ ⳿ⲛⲛⲓⲧⲱⲟⲩ ϫⲉ ϩⲉⲓ ⳿ⲉϫⲱⲛ ⲛⲉⲙ ⲛⲓⲕⲁⲗⲁⲙⲫⲟ ϫⲉ ϩⲟⲃⲥⲉⲛ.
31 Nítorí bí wọn bá ń ṣe nǹkan wọ̀nyí sára igi tútù, kín ni a ó ṣe sára igi gbígbẹ?”
ⲗ̅ⲁ̅ϫⲉ ⲓⲥϫⲉ ⲥⲉ⳿ⲓⲣⲓ ⳿ⲛⲛⲁⲓ ϧⲉⲛ ⲡⲓϣⲉ ⲉⲧⲗⲏ ⲕ ⲓⲉ ⲟⲩ ⲉⲑⲛⲁϣⲱⲡⲓ ϧⲉⲛ ⲡⲉⲧϣⲟⲩⲱⲟⲩ.
32 Àwọn méjì mìíràn bákan náà, àwọn arúfin, ni wọ́n sì fà lọ pẹ̀lú rẹ̀ láti pa.
ⲗ̅ⲃ̅ⲛⲁⲩ⳿ⲓⲛⲓ ⲇⲉ ⳿ⲛⲕⲉⲣⲉϥⲉⲣⲡⲉⲧϩⲱⲟⲩ ⲃ̅ ⲛⲉⲙⲁϥ ⳿ⲉϧⲟⲑⲃⲟⲩ.
33 Nígbà tí wọ́n sì dé ibi tí a ń pè ní Agbárí, níbẹ̀ ni wọ́n gbé kàn án mọ́ àgbélébùú, àti àwọn arúfin náà, ọ̀kan ní ọwọ́ ọ̀tún, àti ọ̀kan ní ọwọ́ òsì.
ⲗ̅ⲅ̅ⲟⲩⲟϩ ⲉⲧⲁⲩ⳿ⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲡⲓⲙⲁ ⲧⲟⲩⲙⲟⲩϯ ⳿ⲉⲣⲟϥ ϫⲉ ⲡⲓ⳿ⲕⲣⲁⲛⲓⲟⲛ ⲁⲩⲁϣϥ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲛⲉⲙ ⲛⲓⲕⲁⲕⲟⲩⲣⲅⲟⲥ ⲟⲩⲁⲓ ⲙⲉⲛ ⲥⲁⲟⲩ⳿ⲓⲛⲁⲙ ⲟⲩⲁⲓ ⲇⲉ ⲥⲁϫⲁϭⲏ ⲁⲩⲫⲱϣ ⲇⲉ ⳿ⲛⲛⲉϥ⳿ϩⲃⲱⲥ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲁⲩ ⲁⲩϩⲓⲱⲡ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ.
34 Jesu sì wí pé, “Baba, dáríjì wọ́n; nítorí tí wọn kò mọ ohun tí wọ́n ń ṣe.” Wọ́n di ìbò láti pín aṣọ rẹ̀ láàrín ara wọn.
ⲗ̅ⲇ̅ⲓ̅ⲥ ⲇⲉ ⲡⲉϫⲁϥ ϫⲉ ⲡⲁⲓⲱⲧ ⲭⲱ ⲛⲱⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϫⲉ ⳿ⲙⲡⲟⲩ⳿ⲉⲙⲓ ⳿ⲉⲛⲏ⳿ⲉⲧⲟⲩ⳿⳿ⲓⲣⲓ ⳿ⲙⲙⲟϥ.
35 Àwọn ènìyàn sì dúró láti wòran. Àti àwọn ìjòyè pẹ̀lú wọn, wọ́n ń yọ ṣùtì sí i, wí pé, “Ó gba àwọn ẹlòmíràn là; kí ó gbara rẹ̀ là, bí ó bá ṣe Kristi, àyànfẹ́ Ọlọ́run.”
ⲗ̅ⲉ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁϥⲟϩⲓ ⲉⲣⲁⲧϥ ⲡⲉ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲓⲗⲁⲟⲥ ⲉϥⲛⲁⲩ ⲛⲁⲩⲉⲗⲕϣⲁⲓ ⲇⲉ ⲡⲉ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲓⲕⲉⲁⲣⲭ ⲱⲛ ⲉⲩϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲁϥⲛⲟϩⲉⲙ ⳿ⲛϩⲁⲛⲕⲉⲭ ⲱⲟⲩⲛⲓ ⲙⲁⲣⲉϥⲛⲁϩⲙⲉϥ ⲱϥ ⲥϫⲉ ⲫⲁⲓ ⲡⲉ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ⳿ⲡϣⲏⲣⲓ ⳿ⲙⲫϯ ⲡⲓⲥⲱⲧⲡ.
36 Àti àwọn ọmọ-ogun pẹ̀lú ń fi í ṣe ẹlẹ́yà, wọ́n tọ̀ ọ́ wá, wọ́n ń fi ọtí kíkan fún un.
ⲗ̅ⲋ̅ⲛⲁⲩⲥⲱⲃⲓ ⲇⲉ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲓⲕⲉⲙⲁⲧⲟⲓ ⲉⲩⲛⲏⲟⲩ ϩⲁⲣⲟϥ ⲁⲩ⳿ⲓⲛⲓ ⳿ⲛⲟⲩϩⲉⲙϫ ⲛⲁϥ.
37 Wọ́n sì ń wí pé, “Bí ìwọ bá ṣe ọba àwọn Júù, gba ara rẹ là.”
ⲗ̅ⲍ̅ⲩϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲓⲥϫⲉ ⳿ⲛⲑⲟⲕ ⲡⲉ ⳿ⲡⲟⲩⲣⲟ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓⲓⲟⲩⲇⲁⲓ ⲛⲁϩⲙⲉⲕ.
38 Wọ́n sì kọ̀wé àkọlé sí ìgbèrí rẹ̀ ní èdè Giriki, àti ti Latin, àti tí Heberu pe: Èyí ni Ọba àwọn Júù.
ⲗ̅ⲏ̅ⲛⲉ ⲟⲩⲟⲛ ⲕⲉⲉⲡⲓ⳿ⲅⲣⲁⲫⲏ ⲇⲉ ⲡⲉ ϩⲓϫⲱϥ ⳿ⲙⲙⲉⲧϩⲉⲃⲣⲉⲟⲥ ⲙⲙⲉⲧⲣⲱⲙⲉⲟⲥ ⳿ⲙⲙⲉⲧⲟⲩⲉⲓⲛⲓⲛ ϫⲉ ⲫⲁⲓ ⲡⲉ ⳿ⲡⲟⲩⲣⲟ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓⲓⲟⲩⲇⲁⲓ.
39 Àti ọ̀kan nínú àwọn arúfin tí a gbé kọ́ ń fi ṣe ẹlẹ́yà wí pé, “Bí ìwọ bá ṣe Kristi, gba ara rẹ àti àwa náà là.”
ⲗ̅ⲑ̅ⲟⲩⲁⲓ ⲇⲉ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲛⲓⲕⲁⲕⲟⲩⲣⲅⲟⲥ ⲉⲧⲁⲩⲁϣⲟⲩ ⲛⲉⲙⲁϥ ⲉⲟⲩ⳿ⲁ ⲉⲣⲟϥ ⲡⲉ ⲉϥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲙⲏ ⳿ⲛⲑⲟⲕ ⲁⲛ ⲡⲉ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ⲛⲁϩⲙⲉⲕ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁϩⲙⲉⲛ ϩⲱⲛ.
40 Ṣùgbọ́n èyí èkejì dáhùn, ó ń bá a wí pé, “Ìwọ kò bẹ̀rù Ọlọ́run, tí ìwọ wà nínú ẹ̀bi kan náà?
ⲙ̅ⲁϥⲉⲣⲟⲩⲱ ⲇⲉ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲓⲕⲉⲟⲩⲁⲓ ⲁϥⲉⲣⲉⲡⲓⲧⲓⲙⲁⲛ ⲛⲁϥ ⲡⲉϫⲁϥ ϫⲉ ⲟⲩⲇⲉ ⲫϯ ⳿ⲛⲑⲟⲕ ⳿ⲕⲉⲣϩⲟϯ ⲁⲛ ϧⲁⲧⲉϥϩⲏ ϫⲉ ⲁⲛⲭⲏ ϧⲉⲛ ⲡⲁⲓϩⲁⲡ ⳿ⲛⲟⲩⲱⲧ.
41 Ní tiwa, wọ́n jàre nítorí èrè ohun tí àwa ṣe ni à ń jẹ, ṣùgbọ́n ọkùnrin yìí kò ṣe ohun búburú kan.”
ⲙ̅ⲁ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲁⲛⲟⲛ ⲙⲉⲛ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲙⲉⲑⲙⲏⲓ ⲉⲧⲁⲛϭⲓ ⲕⲁⲧⲁ ⳿ⲡⲉⲙ⳿ⲡϣⲁ ⳿ⲛⲛⲏⲉⲧⲁⲛⲁⲓⲧⲟⲩ ⲫⲁⲓ ⲇⲉ ⳿ⲙⲡⲉϥⲉⲣ ⳿ϩⲗⲓ ⳿ⲙⲡⲉⲧϩⲱⲟⲩ.
42 Ó sì wí pé, “Jesu, rántí mi nígbà tí ìwọ bá dé ìjọba rẹ.”
ⲙ̅ⲃ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁϥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲁⲣⲓⲡⲁⲙⲉⲩⲓ ϩⲟⲧⲁⲛ ⲕϣⲁⲛ⳿ⲓ ϧⲉⲛ ⲧⲉⲕⲙⲉⲧⲟⲩⲣⲟ.
43 Jesu sì wí fún un pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún ọ, lónìí ni ìwọ ó wà pẹ̀lú mi ní Paradise!”
ⲙ̅ⲅ̅ⲟⲩⲟϩ ⲡⲉϫⲁϥ ϫⲉ ⲁⲙⲏⲛ ϯϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲛⲁⲕ ϫⲉ ⳿ⲙⲫⲟⲟⲩ ⲉⲕ⳿ⲉϣⲱⲡⲓ ⲛⲉⲙⲏⲓ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲡⲁⲣⲁⲇⲓⲥⲟⲥ.
44 Ó sì tó ìwọ̀n wákàtí kẹfà ọjọ́, òkùnkùn sì ṣú bo gbogbo ilẹ̀ títí ó fi di wákàtí kẹsànán ọjọ́.
ⲙ̅ⲇ̅ⲩⲟϩ ⲛⲉ ⳿ⲫⲛⲁⲩ ϩⲏⲇⲏ ⳿ⲛⲁϫⲡ ⲋ̅ ⲡⲉ ⲟⲩⲟϩ ⲁ ⲟⲩⲭⲁⲕⲓ ϣⲱⲡⲓ ϩⲓϫⲉⲛ ⳿ⲡⲕⲁϩⲓ ⲧⲏⲣϥ ϣⲁ ⳿ⲫⲛⲁⲩ ⳿ⲛⲁϫⲡ ⲑ̅.
45 Òòrùn sì ṣú òòkùn, aṣọ ìkélé ti tẹmpili sì ya ní àárín méjì.
ⲙ̅ⲉ̅ⲉϥⲛⲁⲙⲟⲩⲛⲕ ⲇⲉ ⳿ⲛϫⲉ ⲓⲣⲏ ⲓⲕⲁⲧⲁⲡⲉⲧⲁⲥⲙⲁ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓⲉⲣⲫⲉⲓ ⲫⲱϧ ϧⲉⲛ ⲧⲉϥⲙⲏϯ.
46 Nígbà tí Jesu sì kígbe lóhùn rara, ó ní, “Baba, ní ọwọ́ rẹ ni mo fi ẹ̀mí mi lé!” Nígbà tí ó sì wí èyí tan, ó jọ̀wọ́ ẹ̀mí rẹ̀.
ⲙ̅ⲋ̅ⲟⲩⲟϩ ⲉⲧⲁϥⲙⲟⲩϯ ⳿ⲛϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲛⲓϣϯ ⳿ⲛ⳿ⲥⲙⲏ ⲡⲉϫⲁϥ ϫⲉ ⲡⲁⲓⲱⲧ ϯϯ ⳿ⲙⲡⲁⲡ͞ⲛⲁ̅ ⳿ⲉ⳿ϧⲣⲏⲓ ⳿ⲉⲛⲉⲕϫⲓϫ ⲟⲩⲟϩ ⲫⲁⲓ ⲉⲧⲁϥϫⲟϥ ⲁϥϯ ⳿ⲙⲡⲓⲡ͞ⲛⲁ̅.
47 Nígbà tí balógun ọ̀rún rí ohun tí ó ṣe, ó yin Ọlọ́run lógo, wí pé, “Dájúdájú olódodo ni ọkùnrin yìí!”
ⲙ̅ⲍ̅ⲉⲧⲁϥⲛⲁⲩ ⲇⲉ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲓⲉⲕⲁⲧⲟⲛⲧⲁⲣⲭ ⲟⲥ ⳿ⲉⲫⲏⲉⲧⲁϥϣⲱⲡⲓ ⲁϥϯⲱⲟⲩ ⳿ⲙⲫϯ ⲉϥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲟⲛⲧⲱⲥ ⲛⲉ ⲡⲁⲓⲣⲱⲙⲓ ⲟⲩ⳿ⲑⲙⲏ ⲓ ⲡⲉ.
48 Gbogbo ìjọ ènìyàn tí ó péjọ láti rí ìran yìí, nígbà tí wọ́n rí ohun tí ó ṣẹlẹ̀ wọ́n lu ara wọn ní oókan àyà, wọ́n sì padà sí ilé.
ⲙ̅ⲏ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲓⲙⲏϣ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⲉⲧⲁⲩ⳿ⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲧⲁⲓⲑⲉⲱⲣⲓ⳿ⲁ ⲉⲧⲁⲩⲛⲁⲩ ⲉⲛⲏⲉⲧⲁⲩϣⲱⲡⲓ ⲁⲩⲧⲁⲥⲑⲟ ⲉⲩⲕⲱⲗϩ ϧⲉⲛ ⲧⲟⲩⲙⲉⲥⲧⲉⲛϩⲏⲧ.
49 Àti gbogbo àwọn ojúlùmọ̀ rẹ̀, àti àwọn obìnrin tí ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn láti Galili wá, wọ́n dúró lókèèrè, wọ́n ń wo nǹkan wọ̀nyí.
ⲙ̅ⲑ̅ⲛⲁⲩⲟϩⲓ ⲇⲉ ⳿ⲉⲣⲁⲧⲟⲩ ϩⲓ⳿ⲫⲟⲩⲉⲓ ⲡⲉ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲉϥⲣⲉⲙ⳿ⲛⲥⲱⲟⲩⲛ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⲉⲙ ϩⲁⲛⲕⲉϩⲓ⳿ⲟⲙⲓ ⲛⲏⲉⲧⲁⲩⲙⲟϣⲓ ⳿ⲛⲥⲱϥ ⲓⲥϫⲉⲛ ϯⲅⲁⲗⲓⲗⲉ⳿ⲁ ⲉⲩⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲛⲁⲓ.
50 Sì kíyèsi i, ọkùnrin kan tí a ń pè ní Josẹfu, láti ìlú àwọn Júù kan tí ń jẹ́ Arimatea. Ó jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ọmọ ìgbìmọ̀, ènìyàn rere, àti olóòtítọ́.
ⲛ̅ⲟⲩⲟϩ ϩⲏⲡⲡⲉ ⲓⲥ ⲟⲩⲣⲱⲙⲓ ⳿ⲉⲡⲉϥⲣⲁⲛ ⲡⲉ ⲓⲱⲥⲏⲫ ⲉⲟⲩⲃⲟⲩⲗⲉⲩⲧⲏⲥ ⲡⲉ ⳿ⲉⲟⲩⲣⲱⲙⲓ ⳿ⲛⲁⲅⲁⲑⲟⲥ ⲡⲉ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛ⳿ⲑⲙⲏⲓ.
51 Òun kò bá wọn fi ohùn sí ìmọ̀ àti ìṣe wọn; Ó wá láti Judea, ìlú àwọn ará Arimatea, òun pẹ̀lú ń retí ìjọba Ọlọ́run.
ⲛ̅ⲁ̅ⲫⲁⲓ ⲛⲁϥϯⲙⲁϯ ⲁⲛ ⲡⲉ ϧⲉⲛ ⲡⲟⲩⲥⲟϭ ⲛⲓ ⲛⲉⲙ ⲧⲟⲩ⳿ⲡⲣⲁⲝⲓⲥ ⲛⲉ ⲟⲩ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲉⲛ ⲁⲣⲓⲙⲁⲑⲉⲁⲥ ⲡⲉ ⲟⲩⲃⲁⲕⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓⲓⲟⲩⲇⲁⲓ ⲫⲏ ⲉⲛⲁϥϫⲟⲩϣⲧ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲁϫⲉⲛ ϯⲙⲉⲧⲟⲩⲣⲟ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ.
52 Ọkùnrin yìí tọ Pilatu lọ, ó sì tọrọ òkú Jesu.
ⲛ̅ⲃ̅ⲫⲁⲓ ⲉⲧⲁϥ⳿ⲓ ϩⲁ ⲡⲓⲗⲁⲧⲟⲥ ϥⲉⲣⲉⲧⲓⲛ ⳿ⲙⲡⲓⲥⲱⲙⲁ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅.
53 Nígbà tí ó sì sọ̀ ọ́ kalẹ̀, ó sì fi aṣọ àlà dì í, ó sì tẹ́ ẹ sínú ibojì tí a gbẹ́ nínú Òkúta, níbi tí a kò tẹ́ ẹnikẹ́ni sí rí.
ⲛ̅ⲅ̅ⲟⲩⲟϩ ⲉⲧⲁϥ⳿ⲉⲛϥ ⲉⲡⲉⲥⲏⲧ ⲁϥⲕⲟⲩⲗⲱⲗϥ ϧⲉⲛ ⲟⲩϣⲉⲛⲧⲱ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥⲭⲁϥ ϧⲉⲛ ⲟⲩ⳿ⲙϩⲁⲩ ⳿ⲉⲁϥϣⲟⲕϥ ⲙⲡⲁⲧⲟⲩⲭⲁ ⳿ϩⲗⲓ ⳿ⲛϧⲏⲧϥ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥ⳿ⲥⲕⲉⲣⲕⲉⲣ ⳿ⲛⲟⲩⲛⲓϣϯ ⳿ⲛⲱⲛⲓ ϩⲓⲣⲉⲛ ⳿ⲫⲣⲟ ⳿ⲙⲡⲓ⳿ⲙϩⲁⲩ.
54 Ó sì jẹ́ ọjọ́ ìpalẹ̀mọ́, ọjọ́ ìsinmi sì kù sí dẹ̀dẹ̀.
ⲛ̅ⲇ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲉ ⲟⲩ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⲡⲉ ⳿ⲙⲡⲁⲣⲁⲥⲕⲉⲩⲏ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲉⲁ ϣⲱⲣⲡ ϣⲱⲡⲓ ⳿ⲙ⳿ⲡⲥⲁⲃⲃⲁⲧⲟⲛ.
55 Àti àwọn obìnrin, tí wọ́n bá a ti Galili wá, tí wọ́n sì tẹ̀lé, wọ́n kíyèsi ibojì náà, àti bí a ti tẹ́ òkú rẹ̀ sílẹ̀.
ⲛ̅ⲉ̅ⲉⲧⲁⲩⲙⲟϣⲓ ⲇⲉ ⳿ⲛⲥⲱϥ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲓϩⲓ⳿ⲟⲙⲓ ⲛⲏⲉⲧⲁⲩ⳿ⲓ ⲛⲉⲙⲁϥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ϯⲅⲁⲗⲓⲗⲉ⳿ⲁ ⲁⲩⲛⲁⲩ ⲉⲡⲓⲉⲙϩⲁⲩ ⲛⲉⲙ ⲡⲓⲣⲏϯ ⲉⲧⲁⲩⲭⲁ ⲡⲉϥⲥⲱⲙⲁ ⳿ⲙⲙⲟϥ.
56 Nígbà tí wọ́n sì padà, wọ́n pèsè ohun olóòórùn dídùn, òróró ìkunra (àti tùràrí tútù); wọ́n sì sinmi ní ọjọ́ ìsinmi gẹ́gẹ́ bí òfin.
ⲛ̅ⲋ̅ⲉⲧⲁⲩⲧⲁⲥⲑⲟ ⲇⲉ ⲁⲩⲥⲉⲃⲧⲉ ϩⲁⲛ⳿ⲥⲑⲟⲓ ⲛⲉⲙ ϩⲁⲛⲥⲟϫⲉⲛ ⲟⲩⲟϩ ⲡⲓⲥⲁⲃⲃⲁⲧⲟⲛ ⲉⲛ ⲁⲩⲉⲣⲏⲥⲩⲭⲁⲍⲓⲛ ⲕⲁⲧⲁ ϯⲉⲛⲧⲟⲗⲏ

< Luke 23 >