< Luke 22 >
1 Àjọ ọdún àìwúkàrà tí à ń pè ní Ìrékọjá sì kù fẹ́ẹ́rẹ́.
Közeledett már a kovásztalan kenyerek ünnepe, amelyet húsvétnak neveztek.
2 Àti àwọn olórí àlùfáà, àti àwọn akọ̀wé ń wá ọ̀nà tí wọn ìbá gbà pa á; nítorí tí wọn ń bẹ̀rù àwọn ènìyàn.
A főpapok és írástudók keresték a módját, hogyan öljék meg őt, mert féltek a néptől.
3 Satani sì wọ inú Judasi, tí à ń pè ní Iskariotu, ọ̀kan nínú àwọn méjìlá.
Bement a sátán Júdásba, akit Iskáriótesnek neveztek, és aki a tizenkettő közül való volt.
4 Ó sì mú ọ̀nà rẹ̀ pọ̀n, ó lọ láti bá àwọn olórí àlùfáà àti àwọn olórí ẹ̀ṣọ́ gbèrò pọ̀, bí òun yóò tí fi í lé wọn lọ́wọ́.
Elment, és megbeszélte a főpapokkal és az elöljárókkal, hogyan adja őt kezükbe.
5 Wọ́n sì yọ̀, wọ́n sì bá a dá májẹ̀mú láti fún un ní owó.
Azok megörültek, és megígérték, hogy pénzt adnak neki.
6 Ó sì gbà; ó sì ń wá àkókò tí ó wọ̀, láti fi í lé wọn lọ́wọ́ láìsí ariwo.
Ő megígérte, hogy jó alkalmat keres, hogy őt kezükbe adja a nép tudta nélkül.
7 Ọjọ́ àìwúkàrà pé, nígbà tí wọ́n ní láti pa ọ̀dọ́-àgùntàn ìrékọjá fún ìrúbọ.
Elérkezett a kovásztalan kenyerek napja, amikor fel kellett áldozni a húsvéti bárányt.
8 Ó sì rán Peteru àti Johanu, wí pé, “Ẹ lọ pèsè ìrékọjá fún wa, kí àwa ó jẹ.”
Jézus elküldte Pétert és Jánost, és ezt mondta: „Menjetek, készítsétek el nekünk a húsvéti bárányt, hogy megehessük.“
9 Wọ́n sì wí fún un pé, “Níbo ni ìwọ ń fẹ́ kí á pèsè sílẹ̀?”
Ezt mondták neki: „Hol akarod, hogy elkészítsük?“
10 Ó sì wí fún wọn pé, “Kíyèsi i, nígbà tí ẹ̀yin bá ń wọ ìlú lọ, ọkùnrin kan tí ó ru ìkòkò omi yóò pàdé yín, ẹ bá a lọ sí ilé tí ó bá wọ̀,
Ő ezt mondta nekik: „Íme, amikor bementek a városba, szembejön veletek egy ember, aki egy korsó vizet visz. Kövessétek őt abba a házba, amelybe bemegy,
11 kí ẹ sì wí fún baálé ilé náà pé, ‘Olùkọ́ wí fún ọ pé, níbo ni gbàngàn àpèjẹ náà gbé wà, níbi tí èmi ó gbé jẹ ìrékọjá pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn mi?’
és ezt mondjátok a ház gazdájának: Ezt üzeni a Mester: Hol van a szállás, ahol megeszem tanítványaimmal a húsvéti bárányt?
12 Òun ó sì fi gbàngàn ńlá kan lókè ilé hàn yín, tí a ṣe lọ́ṣọ̀ọ́, níbẹ̀ ni kí ẹ̀yin pèsè sílẹ̀.”
És ő mutat nektek egy nagy, berendezett felsőszobát, ott készítsétek el.“
13 Wọ́n sì lọ wọ́n sì bá a gẹ́gẹ́ bí ó tí sọ fún wọn, wọ́n sì pèsè ìrékọjá sílẹ̀.
Elmentek, és úgy találták, ahogy mondta nekik, és elkészítették a húsvéti bárányt.
14 Nígbà tí àkókò sì tó, ó jókòó àti àwọn aposteli pẹ̀lú rẹ̀.
Amikor eljött az idő, asztalhoz ült, és vele együtt a tizenkét apostol.
15 Ó sì wí fún wọn pé, “Tinútinú ni èmi fẹ́ fi bá yín jẹ ìrékọjá yìí, kí èmi tó jìyà.
Ezt mondta nekik: „Vágyva vágytam, hogy megegyem a húsvéti bárányt veletek, mielőtt szenvedek.
16 Nítorí mo wí fún yín, Èmi kì yóò jẹ nínú rẹ̀ mọ́, títí a ó fi mú un ṣẹ ní ìjọba Ọlọ́run.”
Mert mondom néktek, hogy többé nem eszem abból, míg be nem teljesedik Isten országában.“
17 Ó sì gba ago, nígbà tí ó sì ti dúpẹ́, ó wí pé, “Gba èyí, kí ẹ sì pín in láàrín ara yín.
Azután vette a poharat, minekutána hálát adott, ezt mondta: „Vegyétek, és osszátok el magatok között,
18 Nítorí mo wí fún yín, Èmi kì yóò mu nínú èso àjàrà mọ́, títí ìjọba Ọlọ́run yóò fi dé.”
mert mondom néktek, hogy nem iszom a szőlőtőkének gyümölcséből, míg el nem jön Isten országa.“
19 Ó sì mú àkàrà, nígbà tí ó sì ti dúpẹ́ ó bù ú, ó sì fi fún wọn, ó wí pé, “Èyí ni ara mí tí a fi fún yín, ẹ máa ṣe èyí ní ìrántí mi.”
És vette a kenyeret, hálát adott, megszegte, nekik adta, ezt mondván: „Ez az én testem, amely értetek adatik: ezt cselekedjétek az én emlékezetemre.“
20 Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ lẹ́yìn oúnjẹ alẹ́, ó sì mú ago wáìnì, ó wí pé, “Ago yìí ni májẹ̀mú tuntun nínú ẹ̀jẹ̀ mi, tí a ta sílẹ̀ fún yín.
Hasonlóképpen vette a poharat is, miután megvacsoráztak, és ezt mondta: „E pohár az új szövetség az én véremben, amely tiérettetek kionttatik.
21 Ṣùgbọ́n ẹ kíyèsi i, ọwọ́ ẹni tí yóò fi mí hàn wà pẹ̀lú mi lórí tábìlì.
De íme, annak a keze, aki engem elárul, az enyémmel együtt van az asztalon.
22 Ọmọ Ènìyàn ń lọ nítòótọ́ bí a tí pinnu rẹ̀, ṣùgbọ́n ègbé ni fún ọkùnrin náà nípasẹ̀ ẹni tí a gbé ti fi í hàn.”
És az Emberfia elmegy ugyan, amint el van rendelve, de jaj annak az embernek, aki elárulja őt.“
23 Wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí béèrè láàrín ara wọn, ta ni nínú wọn tí yóò ṣe nǹkan yìí.
Erre kezdték kérdezni egymás között, hogy vajon ki lehet az közöttük, aki ezt meg fogja tenni.
24 Ìjà kan sì ń bẹ láàrín wọn, ní ti ẹni tí a kà sí olórí nínú wọn.
Versengés is támadt közöttük, hogy ki tekinthető köztük nagyobbnak.
25 Ó sì wí fún wọn pé, “Àwọn ọba aláìkọlà a máa fẹlá lórí wọn, a sì máa pe àwọn aláṣẹ wọn ní olóore.
Erre ő ezt mondta nekik: „A pogányokon uralkodnak királyaik, és akiknek hatalmuk van felettük, jótevőknek hívatják magukat.
26 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kì yóò rí bẹ́ẹ̀; ṣùgbọ́n ẹni tí ó ba pọ̀jù nínú yín kí ó jẹ́ bí ẹni tí o kéré ju àbúrò; ẹni tí ó sì ṣe olórí, bí ẹni tí ń ṣe ìránṣẹ́.
Közöttetek azonban ne így legyen. Hanem aki a legnagyobb közöttetek, olyan legyen, mint aki a legkisebb, és aki vezet, mint aki szolgál.
27 Nítorí ta ni ó pọ̀jù, ẹni tí ó jókòó tí oúnjẹ, tàbí ẹni tí ó ń ṣe ìránṣẹ́. Ẹni tí ó jókòó ti oúnjẹ kọ́ bí? Ṣùgbọ́n èmi ń bẹ láàrín yín bí ẹni tí ń ṣe ìránṣẹ́.
Mert ki a nagyobb? Az, aki az asztalnál ül, vagy aki szolgál? Ugye az, aki az asztalnál ül? De én olyan vagyok közöttetek, mint aki szolgál.
28 Ẹ̀yin ni àwọn tí ó ti dúró tì mí nínú ìdánwò mi.
Ti vagytok azok, akik megmaradtok velem kísértéseimben,
29 Mo sì yan ìjọba fún yín, gẹ́gẹ́ bí Baba mi ti yàn fún mi.
és én nektek adom az országot, amint az én Atyám nekem adta,
30 Kí ẹ̀yin lè máa jẹ, kí ẹ̀yin sì lè máa mu lórí tábìlì mi ní ìjọba mi, kí ẹ̀yin lè jókòó lórí ìtẹ́, àti kí ẹ̀yin lè máa ṣe ìdájọ́ fún àwọn ẹ̀yà Israẹli méjìlá.”
hogy egyetek és igyatok az én asztalomnál az én országomban, és királyi széken üljetek, ítéletet tartva Izrael tizenkét törzse felett.“
31 Olúwa sì wí pé, “Simoni, Simoni, wò ó, Satani fẹ́ láti gbà ọ́, kí ó lè kù ọ́ bí alikama.
Ezt mondta az Úr: „Simon! Simon! Íme, a sátán kikért titeket, hogy megrostáljon, mint a búzát,
32 Ṣùgbọ́n mo ti gbàdúrà fún ọ, kí ìgbàgbọ́ rẹ má ṣe yẹ̀; àti ìwọ nígbà tí ìwọ bá sì padà bọ̀ sípò, mú àwọn arákùnrin rẹ lọ́kàn le.”
de én imádkoztam érted, hogy el ne fogyatkozzék a te hited. Ha majd megtérsz, erősítsd atyádfiait.“
33 Ó sì wí fún un pé, “Olúwa, mo múra tán láti bá ọ lọ sínú túbú, àti sí ikú.”
Ő pedig ezt mondta: „Uram, veled kész vagyok mind börtönbe, mind halálra menni!“
34 Ó sì wí pé, “Mo wí fún ọ, Peteru, àkùkọ kì yóò kọ lónìí tí ìwọ ó fi sẹ́ mi lẹ́ẹ̀mẹ́ta pé, ìwọ kò mọ̀ mí.”
És ő ezt mondta: „Mondom neked, Péter, ma nem szólal meg addig a kakas, míg te háromszor meg nem tagadod, hogy ismersz engem.“
35 Ó sì wí fún wọn pé, “Nígbà tí mo rán yín lọ láìní àpò-owó, àti àpò, àti bàtà, ọ̀dá ohun kan dá yín bí?” Wọ́n sì wí pé, “Rárá!”
Aztán ezt mondta nekik: „Amikor elküldtelek benneteket erszény, táska és saru nélkül, volt-e valamiben hiányotok?“Ők pedig ezt mondták: „Semmiben sem.“
36 Nígbà náà ni ó wí fún wọn pé, “Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ẹni tí ó bá ní àpò-owó kí ó mú un, àti àpò pẹ̀lú; ẹni tí kò bá sì ní idà, kí ó ta aṣọ rẹ̀, kí ó sì fi ra ọ̀kan.
Ezt mondta nekik: „De most, akinek erszénye van, vegye elő, hasonlóképpen a táskát, és akinek nincs kardja, adja el felsőruháját, és vegyen.
37 Nítorí mo wí fún yín pé, ‘Èyí tí a ti kọ̀wé rẹ̀ kò lè ṣe kí ó má ṣẹ lára mi, a sì kà á mọ́ àwọn arúfin.’ Nítorí àwọn ohun wọ̀nyí nípa ti èmi yóò ní ìmúṣẹ.” tí a sì kà á mọ́ àwọn alárékọjá.
Mert mondom nektek, hogy be kell teljesednie rajtam annak, ami meg van írva: »És a gonoszok közé sorolták.« Mert ami rám vonatkozik, az mind beteljesedik.“
38 Wọ́n sì wí pé, “Olúwa, sá wò ó, idà méjì ń bẹ níhìn-ín yìí!” Ó sì wí fún wọn pé, “Ó tó.”
Azok ezt mondták: „Uram, íme, van itt két kard.“Ő pedig ezt mondta: „Elég!“
39 Ó sì jáde, ó sì lọ bí ìṣe rẹ̀ sí òkè olifi, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.
Ezután kiment, és szokása szerint az Olajfák hegyére ment. Követték a tanítványai is.
40 Nígbà tí ó wà níbẹ̀, ó wí fún wọn pé, “Ẹ máa gbàdúrà, kí ẹ̀yin má ṣe bọ́ sínú ìdẹwò.”
Amikor odaért, ezt mondta nekik: „Imádkozzatok, hogy kísértésbe ne essetek.“
41 Ó sì fi wọ́n sílẹ̀ níwọ̀n ìsọ-òkò kan, ó sì kúnlẹ̀ ó sì ń gbàdúrà.
Aztán eltávolodott tőlük, mintegy kőhajításnyira, és térdre esve imádkozott:
42 Wí pé, “Baba, bí ìwọ bá fẹ́, mu ago yìí kúrò lọ́dọ́ mi: ṣùgbọ́n ìfẹ́ ti èmi kọ́, bí kò ṣe tìrẹ ni kí à ṣe.”
„Atyám, ha akarod, vedd el tőlem ezt a poharat, mégis ne az én akaratom legyen meg, hanem a tiéd.“
43 Angẹli kan sì yọ sí i láti ọ̀run wá, ó ń gbà á ní ìyànjú.
Akkor egy angyal jelent meg a mennyből, és erősítette őt.
44 Bí ó sì ti wà nínú gbígbóná ara ó ń gbàdúrà sí i kíkankíkan; òógùn rẹ̀ sì dàbí ìró ẹ̀jẹ̀ ńlá, ó ń kán sílẹ̀.
Haláltusájában még buzgóbban imádkozott, és verítéke olyan volt, mint a nagy vércseppek, amelyek a földre hullanak.
45 Nígbà tí ó sì dìde kúrò ní ibi àdúrà, tí ó sì tọ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wá, ó bá wọn, wọ́n ń sùn nítorí ìbànújẹ́ ti mu kí ó rẹ̀ wọ́n.
Miután imádkozása után fölkelt, tanítványaihoz ment, akiket alva talált a szomorúságtól.
46 Ó sì wí fún wọn pé, “Kí ni ẹ̀ yin ń sùn sí? Ẹ dìde, ẹ máa gbàdúrà, kí ẹ̀yin má ṣe bọ́ sínú ìdẹwò.”
Ekkor így szólt hozzájuk: „Miért alusztok? Keljetek fel és imádkozzatok, hogy kísértésbe ne essetek.“
47 Bí ó sì ti ń sọ lọ́wọ́, kíyèsi i, ọ̀pọ̀ ènìyàn, àti ẹni tí a ń pè ní Judasi, ọ̀kan nínú àwọn méjìlá, ó ṣáájú wọn, ó súnmọ́ Jesu láti fi ẹnu kò ó ní ẹnu.
Miközben ezeket mondta, íme, sokaság közeledett, amelynek élén Júdás ment, aki egy a tizenkettő közül, és Jézushoz lépett, hogy megcsókolja.
48 Jesu sì wí fún un pé, “Judasi, ìwọ yóò ha fi ìfẹnukonu fi Ọmọ Ènìyàn hàn?”
Jézus ezt mondta neki: „Júdás, csókkal árulod el az Emberfiát?“
49 Nígbà tí àwọn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ ń wo bí nǹkan yóò ti jásí, wọ́n bi í pé, “Olúwa kí àwa fi idà sá wọn?”
Amikor akik körülötte voltak, látták, hogy mi következik, ezt mondták neki: „Uram, vágjunk közéjük karddal?“
50 Ọ̀kan nínú wọn sì fi idà ṣá ọmọ ọ̀dọ̀ olórí àlùfáà, ó sì gé etí ọ̀tún rẹ̀ sọnù.
És valaki közülük máris rásújtott a főpap szolgájára, és levágta annak jobb fülét.
51 Ṣùgbọ́n Jesu dáhùn ó wí pé, “Ko gbọdọ̀ ṣe èyí mọ.” Ó sì fi ọwọ́ tọ́ ọ ní etí, ó sì wò ó sàn.
Jézus azonban megszólalt, és ezt mondta nekik: „Elég!“És megérintve annak fülét, meggyógyította.
52 Jesu wí fún àwọn olórí àlùfáà, àti àwọn olórí ẹ̀ṣọ́ tẹmpili, àti àwọn alàgbà, tí wọ́n jáde tọ̀ ọ́ wá pé, “Ẹ̀yin ha jáde wá pẹ̀lú idà àti ọ̀kọ̀ bí ẹni tọ ọlọ́ṣà wá?
Jézus így szólt azokhoz, akik hozzámentek, a főpapoknak, a templom elöljáróinak és a véneknek: „Mint egy latorra, úgy jöttetek kardokkal és botokkal.
53 Nígbà tí èmi wà pẹ̀lú yín lójoojúmọ́ ní tẹmpili, ẹ̀yin kò na ọwọ́ mú mi, ṣùgbọ́n àkókò tiyín ni èyí, àti agbára òkùnkùn n jẹ ọba.”
Amikor mindennap veletek voltam a templomban, kezeteket nem vetettétek rám. De ez a ti órátok, és a sötétségnek hatalma.“
54 Wọ́n sì gbá a mú, wọ́n sì fà á lọ, wọ́n sì mú un wá sí ilé olórí àlùfáà. Ṣùgbọ́n Peteru tọ̀ ọ́ lẹ́yìn ní òkèrè.
Akkor elfogták őt, elvezették, és elvitték a főpap házába. Péter távolról követte.
55 Nígbà tí wọ́n sì ti dáná láàrín àgbàlá, tí wọ́n sì jókòó pọ̀, Peteru jókòó láàrín wọn.
Amikor tüzet raktak az udvar közepén, és körülülték, Péter is leült velük.
56 Ọmọbìnrin kan sì rí i bí ó ti jókòó níbi ìmọ́lẹ̀ iná náà, ó sì tẹjúmọ́ ọn, ó ní, “Eléyìí náà wà pẹ̀lú rẹ̀.”
Meglátta őt egy szolgálólány, amint a világosságnál ült, szemügyre vette, és ezt mondta: „Ez is vele volt!“
57 Ṣùgbọ́n, ó wí pé, “Obìnrin yìí, èmi kò mọ̀ ọ́n.”
Ő pedig letagadta, és ezt mondta: „Asszony, nem ismerem őt.“
58 Kò pẹ́ lẹ́yìn náà ẹlòmíràn sì rí i, ó ní, “Ìwọ pẹ̀lú wà nínú wọn.” Ṣùgbọ́n Peteru wí pé, “Ọkùnrin yìí, èmi kọ́.”
Rövid idő múlva más valaki látta meg, és mondta: „Te is azok közül való vagy!“Péter pedig ezt mondta: „Ember, nem vagyok!“
59 Ó sì tó bí i wákàtí kan síbẹ̀ ẹlòmíràn tẹnumọ́ ọn, wí pé, “Nítòótọ́ eléyìí náà wà pẹ̀lú rẹ̀: nítorí ará Galili ní í ṣe.”
És úgy egy óra múlva más valaki is bizonygatta, és ezt mondta: „Bizony ez is vele volt, mert Galileából való ő is.“
60 Ṣùgbọ́n Peteru wí pé, “Ọkùnrin yìí, èmi kò mọ ohun tí ìwọ ń wí!” Lójúkan náà, bí ó tí ń wí lẹ́nu, àkùkọ kọ!
Péter ezt mondta: „Ember, nem tudom, mit beszélsz!“És azonnal, amikor még beszélt, megszólalt a kakas.
61 Olúwa sì yípadà, ó wo Peteru. Peteru sì rántí ọ̀rọ̀ Olúwa, bí ó ti wí fún un pé, “Kí àkùkọ tó kọ, ìwọ ó sẹ́ mi lẹ́ẹ̀mẹ́ta.”
Hátrafordult az Úr, és rátekintett Péterre. És Péter visszaemlékezett az Úr szavára, amit neki mondott: „Mielőtt a kakas megszólal, háromszor megtagadsz engem.“
62 Peteru sì bọ́ sí òde, ó sọkún kíkorò.
Aztán kiment, és keservesen sírt.
63 Ó sì ṣe, àwọn ọkùnrin tí wọ́n mú Jesu, sì fi í ṣe ẹlẹ́yà, wọ́n lù ú.
Azok a férfiak, akik fogva tartották Jézust, csúfolták és verték,
64 Nígbà tí wọ́n sì dì í ní ojú, wọ́n lù ú níwájú, wọ́n ń bi í pé, “Sọtẹ́lẹ̀! Ta ni ó lù ọ́?”
és szemét betakarva arcul csapták őt, és ezt kérdezték: „Prófétáld meg, ki az, aki megütött téged!“
65 Wọ́n sì sọ ọ̀pọ̀ ohun búburú mìíràn sí i, láti fi ṣe ẹlẹ́yà.
És sok mással is szidalmazták őt.
66 Nígbà tí ilẹ̀ sì mọ́, ìjọ àwọn alàgbà àwọn ènìyàn péjọpọ̀, àti àwọn olórí àlùfáà, àti àwọn akọ̀wé, wọ́n sì fà á lọ sí àjọ wọn, wọ́n ń wí pé,
Amint nappal lett, egybegyűlt a nép véneinek tanácsa, főpapok és írástudók, és gyülekezetükbe vitték őt,
67 “Bí ìwọ bá jẹ́ Kristi náà? Sọ fún wa!” Ó sì wí fún wọn pé, “Bí mo bá wí fún yín, ẹ̀yin kì yóò gbàgbọ́,
és ezt mondták: „Ha te vagy a Krisztus, mondd meg nekünk.“Ő pedig ezt mondta nekik: „Ha meg is mondanám, akkor sem hiszitek el,
68 bí mo bá sì bi yín léèrè pẹ̀lú, ẹ̀yin kì yóò dá mi lóhùn.
ha pedig én kérdezlek, nem feleltek.
69 Ṣùgbọ́n láti ìsinsin yìí lọ ni Ọmọ Ènìyàn yóò jókòó lọ́wọ́ ọ̀tún agbára Ọlọ́run.”
De mostantól fogva ott ül az Emberfia Isten hatalmának jobbja felől.“
70 Gbogbo wọn sì wí pé, “Ìwọ ha ṣe Ọmọ Ọlọ́run bí?” Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin wí pé, èmi ni.”
Erre mind ezt mondták: „Te vagy tehát Isten Fia?“Ő pedig ezt mondta: „Ti mondjátok, hogy az vagyok!“
71 Wọ́n sì wí pé, “Ẹ̀rí wo ni àwa tún ń fẹ́ àwa tìkára wa sá à ti gbọ́ lẹ́nu rẹ̀!”
Azok ezt mondták: „Mi szükségünk van még tanúkra? Hiszen mi magunk hallottuk saját szájából!“