< Luke 21 >

1 Nígbà tí ó sì gbé ojú sókè, ó rí àwọn ọlọ́rọ̀ ń fi ẹ̀bùn wọn sínú àpótí ìṣúra.
Isusu ăn Hram avizut p bogataši kum ubacăt banji ăn blagajnă alu hramuluj.
2 Ó sì rí tálákà opó kan pẹ̀lú, ó ń sọ owó idẹ wẹ́wẹ́ méjì síbẹ̀.
Atunča avizut š p njeka udovică kum arunkă samo duavă maj mič kovanic.
3 Ó sì wí pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, tálákà opó yìí fi sí i ju gbogbo wọn lọ,
Isusu azăs alu učenikulor: “Punjec urjajke, k istina je, asta sărakă udovică apus maj mult njego jej toc zajedno!
4 nítorí gbogbo àwọn wọ̀nyí fi sínú ẹ̀bùn Ọlọ́run láti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìní wọn; ṣùgbọ́n òun nínú àìní rẹ̀ ó sọ gbogbo ohun ìní rẹ̀ tí ó ní sínú rẹ̀.”
K toc jej adat ča vut viška, a ja, aša d sărakă, adat tot če arje.”
5 Bí àwọn kan sì ti ń sọ̀rọ̀ nípa tẹmpili, bí a ti fi òkúta dáradára àti ẹ̀bùn ṣe é ní ọ̀ṣọ́, fun Ọlọ́run, Jesu wí pé
Kănd njeki učenikurlje alu Isusuluj arubit kum je Hramu sagradit d maj măndru buluvan š ukrasăt ku maj măndri darurj karje lumja adat alu Dimizov, Isusu zăče:
6 “Ohun tí ẹ̀yin ń wò wọ̀nyí, ọjọ́ ń bọ̀, nígbà tí a kì yóò fi òkúta kan sílẹ̀ lórí èkejì tí a kì yóò wó lulẹ̀.”
“Osă vije vrijamja kănd nusă rămije nič unu buluvan p buluvan d Hramusta če vu ujtac. Tot s fije duburăt.”
7 Wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, pé, “Olùkọ́, nígbà wo ni nǹkan wọ̀nyí yóò rí bẹ́ẹ̀? Àti àmì kín ni yóò wà, nígbà tí nǹkan wọ̀nyí yóò fi ṣẹ?”
Š daja jej la antribat: “Učiteljulje, kănd tot aja osă dogodjaštje? D karje znak osă najavljaskă d tot aja če vinje?”
8 Ó sì wí pé, “Ẹ máa kíyèsára, kí a má bá à mú yín ṣìnà: nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ yóò wá ní orúkọ mi, tí yóò máa wí pé, ‘Èmi ní Kristi náà àkókò náà sì kù sí dẹ̀dẹ̀.’ Ẹ má ṣe tọ̀ wọ́n lẹ́yìn.
Ja zăs Isusu: “Păzăcăvă s nu vu ănšalje! Mulc osă vije š osă zăkă: ‘Jo sănt Mesija’ š osă zăkă avinjit kraju! Nu lji kridjec.
9 Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹ̀yin bá gbúròó ogun àti ìdágìrì, ẹ má ṣe fòyà; nítorí nǹkan wọ̀nyí ní láti kọ́kọ́ ṣẹlẹ̀, ṣùgbọ́n òpin náà kì í ṣe lójúkan náà.”
Kănd audjec d raturj š d pobună, na vjec frikă. Tot aja mora s dogodjaskă, ali kraju alu pămăntuluj nusă vije još.”
10 Nígbà náà ni ó wí fún wọn pé, “Orílẹ̀-èdè yóò dìde sí orílẹ̀-èdè, àti ìjọba sí ìjọba.
Zăče još: “Narodu osă zaratjaskă păntruv narod š cara păntruv cară.
11 Ilẹ̀-rírì ńlá yóò sì wà káàkiri, àti ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn; ohun ẹ̀rù, àti àmì ńlá yóò sì ti ọ̀run wá.
Osă fije marj potresurj. Osă fije fuamja š kuga p altje lokurj. Osă fije događajurj d karje lumja osă fije frikă š znakurj p čerj k vinje nješto rov.
12 “Ṣùgbọ́n ṣáájú gbogbo nǹkan wọ̀nyí, wọn ó nawọ́ mú yín, wọn ó sì ṣe inúnibíni sí yín, wọn ó mú yín lọ sí Sinagọgu, àti sínú túbú, wọn ó mú yín lọ sọ́dọ̀ àwọn ọba àti àwọn ìjòyè nítorí orúkọ mi.
Ali majdată d aja če s fije, osă vu apukă š osă vu maltetirjaskă. Osă vu dja ăn sinagogă la sud š p voj osă trimjată ăn kisuarje. Osă vu dukă la intja alu carurj š la upraviteljurj daja če sljidic p minje.
13 Ẹ o si jẹ́rìí nípa mi.
Osă vu zadisaskă p voj s putjec s rubic svjedočala avuastră d minje.
14 Nítorí náà ẹ pinnu rẹ̀ ní ọkàn yín pé ẹ ko ronú ṣáájú, bí ẹ ó ti dáhùn.
Nu vu brinic akuma če s zăčec d minje ăn obrană
15 Nítorí tí èmi ó fún yín ní ẹnu àti ọgbọ́n, tí gbogbo àwọn ọ̀tá yín kì yóò lè sọ̀rọ̀-òdì sí, tí wọn kì yóò sì lè kò lójú.
k jo osă vu dav vorbilje š mudrost karje ničunu alu voštri protivnikurj nusă puată s odoljaskă nič s ăntuarkă vorba.
16 A ó sì fi yín hàn láti ọwọ́ àwọn òbí yín wá, àti àwọn arákùnrin, àti àwọn ìbátan, àti àwọn ọ̀rẹ́; òun ó sì mú kì a pa nínú yín.
Čak š roditelji, fracă, familija, š ortači osă vu predajaskă. Osă vu umuară p njeko d voj.
17 A ó sì kórìíra yín lọ́dọ̀ gbogbo ènìyàn nítorí orúkọ mi.
Toc osă vu zamrzaskă daja če sljidic p minje.
18 Ṣùgbọ́n irun orí yín kan kì yóò ṣègbé.
Ali ničuna d ăštja stvarurj vuavă stvarno nu puatje s vu naštitjaskă.
19 Nínú ìdúró ṣinṣin yín ni ẹ̀yin ó jèrè ọkàn yín.
Osă dobidic život akă mije răminjec vjerni.”
20 “Nígbà tí ẹ̀yin bá sì rí ti a fi ogun yí Jerusalẹmu ká, ẹ mọ̀ nígbà náà pé, ìsọdahoro rẹ̀ kù sí dẹ̀dẹ̀.
“Kănd vidjec k vuastja opkoljaštje Jeruzalemu, osă štijic k avinjit vrijamja d uništijala alu Jeruzalem.
21 Nígbà náà ni kí àwọn tí ń bẹ ní Judea sálọ sórí òkè; àti àwọn tí ń bẹ láàrín rẹ̀ kí wọn jáde kúrò; kí àwọn tí ó sì ń bọ̀ ní ìgbèríko má ṣe wọ inú rẹ̀ wá.
Ălja karje sa trefit ăn Judeja atunča s fugă ăn djal. Činje je ăn trg atunča s fugă dăn jel, a ălja karje s găsaštje ăn okolică atunča s nu untră ăn trg.
22 Nítorí ọjọ́ ẹ̀san ni ọjọ́ wọ̀nyí, kì a lè mú ohun gbogbo tí a ti kọ̀wé rẹ̀ ṣẹ.
K aja osă fije zăljilje alu Dimizovuluj d kaznjală ku karje osă ispunjaskă tot če skrije ăn Svăntă pismă d asta vrijamje.
23 Ṣùgbọ́n ègbé ni fún àwọn tí ó lóyún, àti àwọn tí ó fi ọyàn fún ọmọ mu ní ọjọ́ wọ̀nyí! Nítorí tí ìpọ́njú púpọ̀ yóò wà lórí ilẹ̀ àti ìbínú sí àwọn ènìyàn wọ̀nyí.
Grjev alu trudnicilor š alu mujerj karje dă s sugă ăn vrijamjaja daja če osă vije marje rovu ăn pămăntusta š marje gnjev osă kadă p narodusta.
24 Wọn ó sì ti ojú idà ṣubú, a ó sì dìwọ́n ní ìgbèkùn lọ sí orílẹ̀-èdè gbogbo; Jerusalẹmu yóò sì di ìtẹ̀mọ́lẹ̀ lẹ́sẹ̀ àwọn aláìkọlà, títí àkókò àwọn aláìkọlà yóò fi kún.
Vuastja osă umuarje p njeka lumja š p alci osă lja dukă kašă p ratne zarobljenikurlje ăn tot pămăntu. Nežidovi osă gazaskă p Jeruzalemu pănă god nu triča vrijamja alor.”
25 “Àmì yóò sì wà ní oorun, àti ní òṣùpá, àti ní ìràwọ̀; àti lórí ilẹ̀ ayé ìdààmú fún àwọn orílẹ̀-èdè nínú ìpayà híhó Òkun àti ìgbì omi.
“Osă pojavjaskă čudne znakurj p suarje, p lună š p stjalje. A p pămănt osă fije marje zbunjală, ka valurlje alu apăj ăntră marje oluje. Păntruv aja tot narodu osă fije mult zabrinic š ispunic ku frikă.
26 Àyà àwọn ènìyàn yóò máa já fún ìbẹ̀rù, àti ìrètí nǹkan wọ̀nyí tí ń bọ̀ sórí ayé: nítorí àwọn agbára ọ̀run ni a ó mì tìtì.
Čak š stjaljilje p čerj osă skutirje. Lumja osă muarje d frikă š d marje užas karje osă vije p pămănt.
27 Nígbà náà ni wọn ó sì rí Ọmọ Ènìyàn tí yóò máa bọ̀ wá nínú àwọsánmọ̀ pẹ̀lú agbára àti ògo ńlá.
Atunča tuată lumja osă vjadă p minje, Bijatu alu Omuluj, kum viuv p oblak ăn marje moć š ăn slavă.
28 Ṣùgbọ́n nígbà tí nǹkan wọ̀nyí bá bẹ̀rẹ̀ sí í ṣẹ, ǹjẹ́ kí ẹ wo òkè, kí ẹ sì gbé orí yín sókè; nítorí ìdáǹdè yín kù sí dẹ̀dẹ̀.”
Kănd aja tot ănčapje s dogodjaskă, avjec inimă š fic pljinj d nadă k Dimizov osă vu oslobodjaskă ăndată.”
29 Ó sì pa òwe kan fún wọn pé, “Ẹ kíyèsi igi ọ̀pọ̀tọ́, àti sí gbogbo igi.
Atunča Isusu lja rubit asta vorbă: “Ujtacăvă la smokvă ili bilo d karje ljemn.
30 Nígbà tí wọ́n bá rúwé, ẹ̀yin rí i, ẹ sì mọ̀ fúnra ara yín pé, ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn kù fẹ́ẹ́rẹ́.
Kănd vidjec pupu alu smokvăj atunča š săngurj štijec k je vara apruapje.
31 Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ náà ni ẹ̀yin, nígbà tí ẹ̀yin bá rí nǹkan wọ̀nyí tí o ṣẹ, kí ẹ̀yin mọ̀ pé, ìjọba Ọlọ́run kù sí dẹ̀dẹ̀.
Isto aša kănd vidjec k vinje aja d čaja amrubit, atunča putjec s fic sigurni k je cara alu Dimizovuluj apruapje.
32 “Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ìran yìí kì yóò rékọjá, títí gbogbo nǹkan wọ̀nyí yóò fi ṣẹ.
Istina je zăk vuavă, asta generacija nusă trjakă pănd tot asta nu s dogudja.
33 Ọ̀run àti ayé yóò rékọjá, ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ mi kì yóò rékọjá.
Čerju š pămăntu osă trjakă, ali vorba amja s rămăje zauvjek!”
34 “Ṣùgbọ́n ẹ máa kíyèsára yín, kí ọkàn yín má ṣe kún fún wọ̀bìà, àti fún ọtí àmupara, àti fún àníyàn ayé yìí, tí ọjọ́ náà yóò sì fi dé bá yín lójijì bí ìkẹ́kùn.
Isusu azăs: “Păzăcăvă š nu fic kašă lumja karje je tupavj d mamurluk š d bjarje ili briga alu životusta. Inače, aja zuvă ruavă p voj osă iznenadjaskă
35 Nítorí bẹ́ẹ̀ ni yóò dé bá gbogbo àwọn tí ń gbé orí gbogbo ilẹ̀ ayé.
kašă zamka. K osă vije p tuată lumje karje stanujaštje p pămănt.
36 Ǹjẹ́ kì ẹ máa ṣọ́nà, kí ẹ sì máa gbàdúrà nígbà gbogbo, kí ẹ ba à lè la gbogbo nǹkan wọ̀nyí tí yóò ṣẹlẹ̀, kí ẹ sì lè dúró níwájú Ọmọ Ènìyàn.”
Ăn tuată vrijamja păzăcăvă š rugacăvă s putjec s avjec snagă s izdržic aštja stvarurj če vinje š fic spremic s stăc la intja amja, la intja alu Bijatu alu Omuluj.”
37 Lọ́sàn án, Jesu a sì máa kọ́ni ní tẹmpili, lóru, a sì máa jáde lọ í wọ̀ ní òkè tí à ń pè ní Òkè Olifi.
Isusu tuată zuvă ănvăca ăn Hram, š sara pljika š provodja nuaptja p djal Masline.
38 Gbogbo ènìyàn sì ń tọ̀ ọ́ wá ní tẹmpili ní kùtùkùtù òwúrọ̀, láti gbọ́rọ̀ rẹ̀.
A tot narodu s skula dănzorja š pljika ăn Hram s puje urjajke la Isusu.

< Luke 21 >