< Luke 20 >
1 Ní ọjọ́ kan, bí ó ti ń kọ́ àwọn ènìyàn ní tẹmpili tí ó sì ń wàásù ìyìnrere, àwọn olórí àlùfáà, àti àwọn akọ̀wé, pẹ̀lú àwọn àgbàgbà dìde sí i.
EIA hoi kekahi, i kekahi o ia mau la, i kana ao ana i kanaka iloko o ka luakini me ka hai mai i ka euanelio, kau ae la na kahuna nui, a me ka poe kakauolelo, a me na lunakahiko;
2 Wọ́n sì wí fún un pé, “Sọ fún wa, àṣẹ wo ni ìwọ fi ń ṣe nǹkan wọ̀nyí? Tàbí ta ni ó fún ọ ní àṣẹ yìí?”
Olelo aku la lakou ia ia, i aku la, E hai mai oe ia makou, ma ka mana hea i hana'i oe i keia mau mea? Nawai hoi ia mana i haawi ia oe?
3 Ó sì dáhùn ó sì wí fún wọn pé, “Èmi pẹ̀lú yóò sì bi yín léèrè ọ̀rọ̀ kan; ẹ sì fi ìdáhùn fún mi.
Olelo mai la oia, i mai la ia lakou, Hookahi a'u mea hoi e ninau aku ai ia oukou, e hai mai hoi oukou ia'u.
4 Ìtẹ̀bọmi Johanu, láti ọ̀run wá ni tàbí láti ọ̀dọ̀ ènìyàn?”
O ka bapetizo ana o Ioane, no ka lani mai anei ia, no na kanaka anei?
5 Wọ́n sì bá ara wọn gbèrò pé, “Bí àwa bá wí pé, ‘Láti ọ̀run wá ni,’ òun yóò wí pé, ‘Èéṣe tí ẹ̀yin kò fi gbà á gbọ́?’
A kukakuka lakou lakou iho, i iho la, Ina e olelo aku kakou, No ka lani; e ninau mai no ia, No ke aha la hoi i manaoio ole ai oukou ia ia?
6 Ṣùgbọ́n bí àwa bá sì wí pé, ‘Láti ọ̀dọ̀ ènìyàn,’ gbogbo ènìyàn ni yóò sọ wá ní òkúta, nítorí wọ́n gbàgbọ́ pé, wòlíì ni Johanu.”
A ina o olelo kakou, No na kanaka; e hailuku mai kanaka a pau ia kakou; no ka mea, i ko lakou manao he kaula o Ioane.
7 Wọ́n sì dáhùn wí pé, “Àwa kò mọ̀ ibi tí ó ti wá.”
A olelo aku la lakou, aole lakou i ike i kahi nolaila mai ia.
8 Jesu sì wí fún wọn pé, “Ǹjẹ́ èmi kì yóò wí fún yín àṣẹ tí èmi fi ń ṣe nǹkan wọ̀nyí.”
I mai la hoi o Iesu ia lakou, Aole hoi au e hai aku ia oukou, i ka mana a'u i haua aku ai i keia mau mea.
9 Nígbà náà ni ó bẹ̀rẹ̀ sí í pa òwe yìí fún àwọn ènìyàn pé, “Ọkùnrin kan gbin ọgbà àjàrà kan, ó sì fi ṣe àgbàtọ́jú fún àwọn olùṣọ́gbà, ó sì lọ sí àjò fún ìgbà pípẹ́.
Alaila olelo mai oia i kanaka i keia olelonane; Kanu iho la kekahi kanaka i ka malawaina, a waiho aku ia i na hoaaina, a hele aku la a liuliu loa ma ka aina e.
10 Nígbà tí ó sì tó àkókò, ó rán ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ kan sí àwọn olùṣọ́gbà náà, kí wọn lè fún un nínú èso ọgbà àjàrà náà, ṣùgbọ́n àwọn alágbàtọ́jú lù ú, wọ́n sì rán an padà lọ́wọ́ òfo.
A i ka manawa pono, hoouna mai la ia i kahi kauwa i ka poe hoaaina i haawi lakou ia ia i ka hua o ka malawaina; a pepehi iho la na hoaaina ia ia, a hoihoi nele aku la ia ia.
11 Ó sì tún rán ọmọ ọ̀dọ̀ mìíràn, wọ́n sì lù ú pẹ̀lú, wọ́n sì jẹ ẹ́ ní yà, wọ́n sì rán an padà lọ́wọ́ òfo.
Alaila hoouna hou mai la oia i kekahi kauwa; a pepehi hou lakou ia ia, a hoomainoino, a hoihoi nele aku la ia ia.
12 Ó sì tún rán ẹ̀kẹta: wọ́n sì sá a lọ́gbẹ́ pẹ̀lú, wọ́n sì tì í jáde.
A mahope iho, hoouna hou mai la oia i ke kolu; a hana eha aku la lakou ia ia, a kipaku aku la.
13 “Nígbà náà ni Olúwa ọgbà àjàrà wí pé, ‘Èwo ni èmi ó ṣe? Èmi ó rán ọmọ mi àyànfẹ́ lọ: bóyá nígbà tí wọ́n bá rí i, wọn yóò bu ọlá fún un.’
Alaila i iho la ka haku o ka malawaina, Pehea la wau e hana'i? E hoouna aku au i ka'u keiki punahele, aia ike lakou ia ia, e manao mahalo mai paha lakou ia ia.
14 “Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn alágbàtọ́jú náà rí i, wọ́n bá ara wọn gbèrò pé, ‘Èyí ni àrólé; ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a pa á, kí ogún rẹ̀ lè jẹ́ ti wa.’
A ike ua poe hoaaina la ia ia, kamailio iho la lakou ia lakou iho, i iho la, Eia ka hooilina; ina hoi! e pepehi kakou ia ia a make, i lilo io mai ka aina ia kakou.
15 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì tì í jáde sẹ́yìn ọgbà àjàrà, wọ́n sì pa á. “Ǹjẹ́ kín ni olúwa ọgbà àjàrà náà yóò ṣe sí wọn?
A kipaku aku la lakou ia ia mawaho o ka malawaina, pepehi iho la a make. Heaha la hoi ka ka haku nona ka malawaina e hana mai ai ia lakou?
16 Yóò wá, yóò sì pa àwọn alágbàtọ́jú náà run, yóò sì fi ọgbà àjàrà náà fún àwọn ẹlòmíràn.” Nígbà tí wọ́n sì gbọ́, wọ́n ní, “Kí a má ri i!”
E hele mai no ia a luku mai ia poe hoaaina, a e haawi aku i ka malawaina i kekahi poe e. Olelo iho la ka poe e hoolohe ana, Aole loa ia!
17 Nígbà tí ó sì wò wọ́n, ó ní, “Èwo ha ni èyí tí a ti kọ̀wé rẹ̀ pé: “‘Òkúta tí àwọn ọ̀mọ̀lé kọ̀sílẹ̀, òun náà ni ó di pàtàkì igun ilé’?
A nana mai la oia ia lakou, i mai la, Heaha hoi ke ano o keia i palapalaia, O ka pohaku a ka poe nana hale i haalele ai, oia ke hooliloia i pohaku kumu no ke kihi?
18 Ẹnikẹ́ni tí ó ṣubú lu òkúta náà yóò fọ́; ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí òun bá ṣubú lù, yóò lọ̀ ọ́ lúúlúú.”
O ka mea e haule maluna iho o ua pohaku la, e haihaiia oia, a o ka mea e hioloia'i e ia, e pepe loa no ia.
19 Àwọn olórí àlùfáà àti àwọn akọ̀wé ń wá ọ̀nà láti mú un ní wákàtí náà; ṣùgbọ́n wọ́n bẹ̀rù àwọn ènìyàn, nítorí tí wọ́n mọ̀ pé, ó pa òwe yìí mọ́ wọn.
A imi iho la ka poe kahuna nui, a me ka poe kakauolelo e kau na lima maluna ona ia manawa, aka, ua makau lakou i kanaka: no ka mea, ua ike lakou, ua olelo mai oia i keia olelonane no lakou.
20 Wọ́n sì ń ṣọ́ ọ, wọ́n sì rán àwọn ayọ́lẹ̀wò tí wọ́n ṣe ara wọn bí ẹni pé olóòtítọ́ ènìyàn, kí wọn ba à lè gbá ọ̀rọ̀ rẹ̀ mú, kí wọn ba à lè fi í lé agbára àti àṣẹ Baálẹ̀ lọ́wọ́.
A kiai aku la lakou ia ia, a hoouna ae la i na kiu e hookamani ia lakou iho he mau kanaka pono; e hoohihia ia ia i kana olelo, e haawi aku lakou ia ia i ka lima a me ka mana o ke kiaaina;
21 Wọ́n sì bí i, pé, “Olùkọ́ àwa mọ̀ pé, ìwọ a máa sọ̀rọ̀ fún ni, ìwọ a sì máa kọ́ni bí ó ti tọ́, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì í ṣe ojúsàájú ẹnìkan ṣùgbọ́n ìwọ ń kọ́ni ní ọ̀nà Ọlọ́run lóòtítọ́.
A ninau aku lakou ia ia, i aku la, E ke kumu, ua ike makou he pololei kau olelo ana a me kau ao ana, aole oe i manao ia waho, aka, ua hoike oe i ka aoao o ke Akua me ka oiaio;
22 Ǹjẹ́ ó tọ́ fún wa láti máa san owó òde fún Kesari, tàbí kò tọ́?”
He pono anei ke hookupu makou ia Kaisara, aole anei?
23 Ṣùgbọ́n ó kíyèsi àrékérekè wọn, ó sì wí fún wọn pé,
Ike no hoi oia i ko lakou maalea, i mai la ia lakou, No ke aha la oukou i hoohuahualau mai nei ia'u?
24 “Ẹ fi owó idẹ kan hàn mí. Àwòrán àti àkọlé ti ta ni ó wà níbẹ̀?” Wọ́n sì dá a lóhùn pé, “Ti Kesari ni.”
E hoike mai oukou ia'u i kahi denari; nowai kona kii a me ka palapala? Hai aku la lakou, i aku la hoi, No Kaisara.
25 Ó sì wí fún wọn pé, “Ǹjẹ́ ẹ fi ohun tí i ṣe ti Kesari fún Kesari, àti ohun tí í ṣe ti Ọlọ́run fún Ọlọ́run.”
I mai la oia ia lakou, E haawi aku hoi i ka Kaisara ia Kaisara, a i ka ke Akua i ke Akua.
26 Wọn kò sì lè gbá ọ̀rọ̀ rẹ̀ mú níwájú àwọn ènìyàn: ẹnu sì yà wọ́n sí ìdáhùn rẹ̀, wọ́n sì pa ẹnu wọn mọ́.
Aole e hiki ia lakou ke hoohihia ia ia ma kana olelo imua o ke alo o kanaka: a kakanu iho la lakou me ka mahalo i ka olelo ana i hai mai ai.
27 Àwọn Sadusi kan sì tọ̀ ọ́ wá, àwọn tí wọ́n ń wí pé àjíǹde òkú kò sí wọ́n sì bi í,
Alaila hele ae la kekahi o ka poe Sadukaio, ka poe i hoole i ke alahouana: ninau aku la lakou ia ia,
28 wí pé, “Olùkọ́, Mose kọ̀wé fún wa pé, Bí arákùnrin ẹnìkan bá kú, ní àìlọ́mọ, tí ó sì ní aya, kí arákùnrin rẹ̀ ṣú aya rẹ̀ lópó, kí ó lè gbé irú-ọmọ dìde fún arákùnrin rẹ̀.
I aku la, E ke Kumu, ua palapala mai o Mose ia makou, O ka mea ua make kona kaikuaana ka mea wahine, a i make keiki ole, e mare aku kona kaikaina i kana wahine, a e hoohanau keiki na kona kaikuaana.
29 Ǹjẹ́ àwọn arákùnrin méje kan ti wà; èkínní gbé ìyàwó, ó sì kú ní àìlọ́mọ.
Ehiku no hoahanau kane; a mare aku la ka mua i ka wahine, a make keiki ole ia.
30 Èkejì sì ṣú u lópó: òun sì kú ní àìlọ́mọ.
A mare iho la kona hope mai i ua wahine la, a make keiki ole no hoi ia.
31 Ẹ̀kẹta sì ṣú u lópó: gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn méjèèje pẹ̀lú: wọn kò sì fi ọmọ sílẹ̀, wọ́n sì kú.
A o ke kolu hoi, ua mare aku la oia ia ia, a pela no hoi lakou a ehiku; make iho la lakou, aole a lakou keiki.
32 Nígbẹ̀yìn pátápátá obìnrin náà kú pẹ̀lú.
A mahope o lakou a pau, make iho la no hoi ua wahine la.
33 Ǹjẹ́ ní àjíǹde òkú, aya ti ta ni yóò ha ṣe nínú wọn? Nítorí àwọn méjèèje ni ó sá à ni í ní aya.”
A i ke alahouana, owai la ka mea o lakou ia ia ka wahine? No ka mea, ua mare lakou a ehiku ia ia.
34 Jesu sì dáhùn ó wí fún wọn pé, “Àwọn ọmọ ayé yìí a máa gbéyàwó, wọn a sì máa fa ìyàwó fún ni. (aiōn )
Hai mai la Iesu, i mai la ia lakou, O ko ke ao nei, ua mare lakou, a ua hoopalauia no hoi; (aiōn )
35 Ṣùgbọ́n àwọn tí a kà yẹ láti jogún ìyè ayérayé náà, àti àjíǹde kúrò nínú òkú, wọn kì í gbéyàwó, wọn kì í sì í fa ìyàwó fún ni. (aiōn )
Aka, o ka poe e pono ke loaa pu ia lakou kela ao aku me ka hoala hou ia mai mai waena mai o ka poe make, aole o lakou e mare, aole no hoi e hoopalauia. (aiōn )
36 Nítorí wọn kò lè kú mọ́; nítorí tí wọn bá àwọn angẹli dọ́gba; àwọn ọmọ Ọlọ́run sì ni wọ́n, nítorí wọ́n di àwọn ọmọ àjíǹde.
No ka mea, aole e hiki ia lakou ke make hou, no ka mea, e like no lakou me ka poe anela; he poe keiki hoi lakou na ke Akua, na keiki hoi o ke alahouana.
37 Ní ti pé a ń jí àwọn òkú dìde, Mose tìkára rẹ̀ sì ti fihàn nínú igbó, nígbà tí ó pe ‘Olúwa ni Ọlọ́run Abrahamu, àti Ọlọ́run Isaaki, àti Ọlọ́run Jakọbu.’
A no ka hoala hou ana o ka poe i make, ua hoike mai o Mose ma ka laau i kona kapa ana i ka Haku, ke Akua no Aberahama, ke Akua no Isaaka, ke Akua no Iakoba.
38 Bẹ́ẹ̀ ni òun kì í ṣe Ọlọ́run àwọn òkú, bí kò ṣe ti àwọn alààyè, nítorí gbogbo wọn wà láààyè fún un.”
Aole hoi ia he Akua no ka poe make, aka, no ka poe ola; no ka mea, e ola ana lakou a pau ia ia.
39 Nígbà náà ni àwọn kan nínú àwọn akọ̀wé dá a lóhùn, pé, “Olùkọ́ ìwọ wí rere!”
Alaila olelo aku la kekahi poe kakauolelo, i aku la, E ke Kumu, ua pono kau olelo ana.
40 Wọn kò sì jẹ́ bi í léèrè ọ̀rọ̀ kan mọ́.
Aole hoi o lakou i aa e ninau hou aku ia ia.
41 Ó sì wí fún wọn pé, “Èéṣe tí wọ́n fi ń wí pé, ọmọ Dafidi ni Kristi?
A i mai la oia ia lakou, Pehea la hoi lakou i olelo ai, He keiki ka Mesia na Davida?
42 Dafidi tìkára rẹ̀ sì wí nínú ìwé Saamu pé: “‘Olúwa sọ fún Olúwa mi pé: “Ìwọ jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún mi
A o Davida kekahi i olelo mai ma ka buke Halelu, I mai la o Iehova i kuu Haku, E noho oe ma ko'u lima akau,
43 títí èmi ó fi sọ àwọn ọ̀tá rẹ di àpótí ìtìsẹ̀ rẹ.”’
A hoolilo iho au i kou poe enemi i paepae no kou mau wawae.
44 Ǹjẹ́ bí Dafidi bá pè é ní ‘Olúwa.’ Òun ha sì ti ṣe jẹ́ ọmọ rẹ̀?”
Nolaila, ina pela o Davida i kapa ai ia ia i Haku, pehea la hoi ia e keiki ai nana?
45 Ó sì wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ní etí gbogbo ènìyàn pé,
A i ka hoolohe ana o ka poe kanaka, olelo mai la oia i kana poe haumana,
46 “Ẹ máa kíyèsára lọ́dọ̀ àwọn akọ̀wé, tí wọ́n fẹ́ láti máa rìn nínú aṣọ gígùn, tí wọ́n sì fẹ́ ìkíni ní ọjà, àti ibùjókòó ọlá nínú Sinagọgu, àti ipò ọlá ní ibi àsè;
E malama ia oukou iho i ka poe kakauolelo, ka poe i makemake e hele me ka lole hooluelue, a me ke alohaia mai ma kahi kanaka, a me na noho kiekie maloko o na halehalawai, a me na wahi maikai loa i na ahaaina;
47 Àwọn tí ó jẹ ilé àwọn opó run, tí wọ́n sì ń gbàdúrà gígùn fún àṣehàn, àwọn wọ̀nyí náà ni yóò jẹ̀bi pọ̀jù.”
Ka poe i hoopau i na hale o na wahinekanemake, a hooloihi hoi i ka pule i ikeia mai ai; e nui auanei hoi ko lakou make.