< Luke 2 >
1 Ó sì ṣe ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àṣẹ ti ọ̀dọ̀ Kesari Augustu jáde wá pé, kí a kọ orúkọ gbogbo ayé sínú ìwé.
ཨཔརཉྩ ཏསྨིན྄ ཀཱལེ རཱཛྱསྱ སཪྻྭེཥཱཾ ལོཀཱནཱཾ ནཱམཱནི ལེཁཡིཏུམ྄ ཨགསྟཀཻསར ཨཱཛྙཱཔཡཱམཱས།
2 (Èyí ni ìkọ sínú ìwé èkínní tí a ṣe nígbà tí Kirene fi jẹ baálẹ̀ Siria.)
ཏདནུསཱརེཎ ཀུརཱིཎིཡནཱམནི སུརིཡཱདེཤསྱ ཤཱསཀེ སཏི ནཱམལེཁནཾ པྲཱརེབྷེ།
3 Gbogbo àwọn ènìyàn sì lọ láti kọ orúkọ wọn sínú ìwé, olúkúlùkù sí ìlú ara rẹ̀.
ཨཏོ ཧེཏོ རྣཱམ ལེཁིཏུཾ སཪྻྭེ ཛནཱཿ སྭཱིཡཾ སྭཱིཡཾ ནགརཾ ཛགྨུཿ།
4 Josẹfu pẹ̀lú sì gòkè láti Nasareti ni Galili, sí ìlú Dafidi ní Judea, tí à ń pè ní Bẹtilẹhẹmu; nítorí ti ìran àti ìdílé Dafidi ní í ṣe,
ཏདཱནཱིཾ ཡཱུཥཕ྄ ནཱམ ལེཁིཏུཾ ཝཱགྡཏྟཡཱ སྭབྷཱཪྻྱཡཱ གརྦྦྷཝཏྱཱ མརིཡམཱ སཧ སྭཡཾ དཱཡཱུདཿ སཛཱཏིཝཾཤ ཨིཏི ཀཱརཎཱད྄ གཱལཱིལྤྲདེཤསྱ ནཱསརཏྣགརཱད྄
5 láti kọ orúkọ rẹ̀, pẹ̀lú Maria aya rẹ̀ àfẹ́sọ́nà, tí oyún rẹ̀ ti tó bí.
ཡིཧཱུདཱཔྲདེཤསྱ བཻཏླེཧམཱཁྱཾ དཱཡཱུདྣགརཾ ཛགཱམ།
6 Ó sì ṣe, nígbà tí wọ́n wà níbẹ̀, ọjọ́ rẹ̀ pé tí òun yóò bí.
ཨནྱཙྩ ཏཏྲ སྠཱནེ ཏཡོསྟིཥྛཏོཿ སཏོ རྨརིཡམཿ པྲསཱུཏིཀཱལ ཨུཔསྠིཏེ
7 Ó sì bí àkọ́bí rẹ̀ ọmọkùnrin, ó sì fi ọ̀já wé e, ó sì tẹ́ ẹ sínú ibùjẹ ẹran; nítorí tí ààyè kò sí fún wọn nínú ilé èrò.
སཱ ཏཾ པྲཐམསུཏཾ པྲཱསོཥྚ ཀིནྟུ ཏསྨིན྄ ཝཱསགྲྀཧེ སྠཱནཱབྷཱཝཱད྄ བཱལཀཾ ཝསྟྲེཎ ཝེཥྚཡིཏྭཱ གོཤཱལཱཡཱཾ སྠཱཔཡཱམཱས།
8 Àwọn olùṣọ́-àgùntàn ń bẹ tí wọ́n ń gbé ní ìlú náà, wọ́n ń ṣọ́ agbo àgùntàn wọn ní òru ní pápá tí wọ́n ń gbé.
ཨནནྟརཾ ཡེ ཀིཡནྟོ མེཥཔཱལཀཱཿ སྭམེཥཝྲཛརཀྵཱཡཻ ཏཏྤྲདེཤེ སྠིཏྭཱ རཛནྱཱཾ པྲཱནྟརེ པྲཧརིཎཿ ཀརྨྨ ཀུཪྻྭནྟི,
9 Angẹli Olúwa sì yọ sí wọn, ògo Olúwa sì ràn yí wọn ká, ẹ̀rù sì bà wọ́n gidigidi.
ཏེཥཱཾ སམཱིཔཾ པརམེཤྭརསྱ དཱུཏ ཨཱགཏྱོཔཏསྠཽ; ཏདཱ ཙཏུཥྤཱརྴྭེ པརམེཤྭརསྱ ཏེཛསཿ པྲཀཱཤིཏཏྭཱཏ྄ ཏེ྅ཏིཤཤངྐིརེ།
10 Angẹli náà sì wí fún wọn pé, “Má bẹ̀rù: sá wò ó, mo mú ìyìnrere ayọ̀ ńlá fún yín wá, tí yóò ṣe ti ènìyàn gbogbo.
ཏདཱ ས དཱུཏ ཨུཝཱཙ མཱ བྷཻཥྚ པཤྱཏཱདྱ དཱཡཱུདཿ པུརེ ཡུཥྨནྣིམིཏྟཾ ཏྲཱཏཱ པྲབྷུཿ ཁྲཱིཥྚོ྅ཛནིཥྚ,
11 Nítorí a ti bí Olùgbàlà fún yín lónìí ní ìlú Dafidi, tí í ṣe Kristi Olúwa.
སཪྻྭེཥཱཾ ལོཀཱནཱཾ མཧཱནནྡཛནཀམ྄ ཨིམཾ མངྒལཝྲྀཏྟཱནྟཾ ཡུཥྨཱན྄ ཛྙཱཔཡཱམི།
12 Èyí ni yóò sì ṣe àmì fún yín; ẹ̀yin yóò rí ọmọ ọwọ́ tí a fi ọ̀já wé, ó dùbúlẹ̀ ní ibùjẹ ẹran.”
ཡཱུཡཾ (ཏཏྶྠཱནཾ གཏྭཱ) ཝསྟྲཝེཥྚིཏཾ ཏཾ བཱལཀཾ གོཤཱལཱཡཱཾ ཤཡནཾ དྲཀྵྱཐ ཡུཥྨཱན྄ པྲཏཱིདཾ ཙིཧྣཾ བྷཝིཥྱཏི།
13 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ogun ọ̀run sì darapọ̀ mọ́ angẹli náà ní òjijì, wọ́n ń yin Ọlọ́run, wí pé,
དཱུཏ ཨིམཱཾ ཀཐཱཾ ཀཐིཏཝཏི ཏཏྲཱཀསྨཱཏ྄ སྭརྒཱིཡཱཿ པྲྀཏནཱ ཨཱགཏྱ ཀཐཱམ྄ ཨིམཱཾ ཀཐཡིཏྭེཤྭརསྱ གུཎཱནནྭཝཱདིཥུཿ, ཡཐཱ,
14 “Ògo ni fún Ọlọ́run lókè ọ̀run, àti ní ayé àlàáfíà, ìfẹ́ inú rere sí ènìyàn.”
སཪྻྭོརྡྭྭསྠཻརཱིཤྭརསྱ མཧིམཱ སམྤྲཀཱཤྱཏཱཾ། ཤཱནྟིརྦྷཱུཡཱཏ྄ པྲྀཐིཝྱཱསྟུ སནྟོཥཤྩ ནརཱན྄ པྲཏི༎
15 Ó sì ṣe, nígbà tí àwọn angẹli náà padà kúrò lọ́dọ̀ wọn lọ sí ọ̀run, àwọn olùṣọ́-àgùntàn náà bá ara wọn sọ pé, “Ẹ jẹ́ kí á lọ tààrà sí Bẹtilẹhẹmu, kí á lè rí ohun tí ó ṣẹ̀, tí Olúwa fihàn fún wa.”
ཏཏཿ པརཾ ཏེཥཱཾ སནྣིདྷེ རྡཱུཏགཎེ སྭརྒཾ གཏེ མེཥཔཱལཀཱཿ པརསྤརམ྄ ཨཝེཙན྄ ཨཱགཙྪཏ པྲབྷུཿ པརམེཤྭརོ ཡཱཾ གྷཊནཱཾ ཛྙཱཔིཏཝཱན྄ ཏསྱཱ ཡཱཐཪྻཾ ཛྙཱཏུཾ ཝཡམདྷུནཱ བཻཏླེཧམྤུརཾ ཡཱམཿ།
16 Wọ́n sì wá lọ́gán, wọ́n sì rí Maria àti Josẹfu, àti ọmọ ọwọ́ náà, ó dùbúlẹ̀ nínú ibùjẹ ẹran.
པཤྩཱཏ྄ ཏེ ཏཱུརྞཾ ཝྲཛིཏྭཱ མརིཡམཾ ཡཱུཥཕཾ གོཤཱལཱཡཱཾ ཤཡནཾ བཱལཀཉྩ དདྲྀཤུཿ།
17 Nígbà tí wọ́n sì ti rí i, wọ́n sọ ohun tí a ti wí fún wọn nípa ti ọmọ yìí.
ཨིཏྠཾ དྲྀཥྚྭཱ བཱལཀསྱཱརྠེ པྲོཀྟཱཾ སཪྻྭཀཐཱཾ ཏེ པྲཱཙཱརཡཱཉྩཀྲུཿ།
18 Ẹnu sì ya gbogbo àwọn tí ó gbọ́ sí nǹkan wọ̀nyí tí a ti wí fún wọn láti ọ̀dọ̀ àwọn olùṣọ́-àgùntàn wá.
ཏཏོ ཡེ ལོཀཱ མེཥརཀྵཀཱཎཱཾ ཝདནེབྷྱསྟཱཾ ཝཱརྟྟཱཾ ཤུཤྲུཝུསྟེ མཧཱཤྩཪྻྱཾ མེནིརེ།
19 Ṣùgbọ́n Maria pa gbogbo nǹkan wọ̀nyí mọ́, ó ń rò wọ́n nínú ọkàn rẹ̀.
ཀིནྟུ མརིཡམ྄ ཨེཏཏྶཪྻྭགྷཊནཱནཱཾ ཏཱཏྤཪྻྱཾ ཝིཝིཙྱ མནསི སྠཱཔཡཱམཱས།
20 Àwọn olùṣọ́-àgùntàn sì padà lọ, wọ́n ń fi ògo fún Ọlọ́run, wọ́n sì yìn ín, nítorí ohun gbogbo tí wọ́n ti gbọ́ àti tí wọ́n ti rí, bí a ti wí i fún wọn.
ཏཏྤཤྩཱད྄ དཱུཏཝིཛྙཔྟཱནུརཱུཔཾ ཤྲུཏྭཱ དྲྀཥྚྭཱ ཙ མེཥཔཱལཀཱ ཨཱིཤྭརསྱ གུཎཱནུཝཱདཾ དྷནྱཝཱདཉྩ ཀུཪྻྭཱཎཱཿ པརཱཝྲྀཏྱ ཡཡུཿ།
21 Nígbà tí ọjọ́ mẹ́jọ sì pé láti kọ ọmọ náà nílà, wọ́n pe orúkọ rẹ̀ ní Jesu, bí a ti sọ ọ́ tẹ́lẹ̀ láti ọ̀dọ̀ angẹli náà wá kí á tó lóyún rẹ̀.
ཨཐ བཱལཀསྱ ཏྭཀྪེདནཀཱལེ྅ཥྚམདིཝསེ སམུཔསྠིཏེ ཏསྱ གརྦྦྷསྠིཏེཿ པུཪྻྭཾ སྭརྒཱིཡདཱུཏོ ཡཐཱཛྙཱཔཡཏ྄ ཏདནུརཱུཔཾ ཏེ ཏནྣཱམདྷེཡཾ ཡཱིཤུརིཏི ཙཀྲིརེ།
22 Nígbà tí ọjọ́ ìwẹ̀nù Maria sì pé gẹ́gẹ́ bí òfin Mose, Josẹfu àti Maria gbé Jesu wá sí Jerusalẹmu láti fi í fún Olúwa
ཏཏཿ པརཾ མཱུསཱལིཁིཏཝྱཝསྠཱཡཱ ཨནུསཱརེཎ མརིཡམཿ ཤུཙིཏྭཀཱལ ཨུཔསྠིཏེ,
23 (bí a ti kọ ọ́ sínú òfin Olúwa pé, “Gbogbo ọmọ ọkùnrin tí ó ṣe àkọ́bí, òun ni a ó pè ní mímọ́ fún Olúwa”),
"པྲཐམཛཿ སཪྻྭཿ པུརུཥསནྟཱནཿ པརམེཤྭརེ སམརྤྱཏཱཾ," ཨིཏི པརམེཤྭརསྱ ཝྱཝསྠཡཱ
24 àti láti rú ẹbọ gẹ́gẹ́ bí èyí tí a wí nínú òfin Olúwa: “Àdàbà méjì tàbí ọmọ ẹyẹlé méjì.”
ཡཱིཤུཾ པརམེཤྭརེ སམརྤཡིཏུམ྄ ཤཱསྟྲཱིཡཝིདྷྱུཀྟཾ ཀཔོཏདྭཡཾ པཱརཱཝཏཤཱཝཀདྭཡཾ ཝཱ བལིཾ དཱཏུཾ ཏེ ཏཾ གྲྀཧཱིཏྭཱ ཡིརཱུཤཱལམམ྄ ཨཱཡཡུཿ།
25 Sì kíyèsi i, ọkùnrin kan wà ní Jerusalẹmu, orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Simeoni; ọkùnrin náà sì ṣe olóòtítọ́ àti olùfọkànsìn, ó ń retí ìtùnú Israẹli, Ẹ̀mí mímọ́ sì bà lé e.
ཡིརཱུཤཱལམྤུརནིཝཱསཱི ཤིམིཡོནྣཱམཱ དྷཱརྨྨིཀ ཨེཀ ཨཱསཱིཏ྄ ས ཨིསྲཱཡེལཿ སཱནྟྭནཱམཔེཀྵྱ ཏསྠཽ ཀིཉྩ པཝིཏྲ ཨཱཏྨཱ ཏསྨིནྣཱཝིརྦྷཱུཏཿ།
26 A sì ti fihàn án láti ọ̀dọ̀ Ẹ̀mí Mímọ́ náà wá pé, òun kì yóò rí ikú, kí ó tó rí Kristi Olúwa.
ཨཔརཾ པྲབྷུཎཱ པརམེཤྭརེཎཱབྷིཥིཀྟེ ཏྲཱཏརི ཏྭཡཱ ན དྲྀཥྚེ ཏྭཾ ན མརིཥྱསཱིཏི ཝཱཀྱཾ པཝིཏྲེཎ ཨཱཏྨནཱ ཏསྨ པྲཱཀཐྱཏ།
27 Ó sì ti ipa Ẹ̀mí wá sínú tẹmpili. Nígbà tí àwọn òbí rẹ̀ sì gbé Jesu wá, láti ṣe fún un bí ìṣe òfin.
ཨཔརཉྩ ཡདཱ ཡཱིཤོཿ པིཏཱ མཱཏཱ ཙ ཏདརྠཾ ཝྱཝསྠཱནུརཱུཔཾ ཀརྨྨ ཀརྟྟུཾ ཏཾ མནྡིརམ྄ ཨཱནིནྱཏུསྟདཱ
28 Nígbà náà ni Simeoni gbé e ní apá rẹ̀, ó fi ìbùkún fún Ọlọ́run, ó ní:
ཤིམིཡོན྄ ཨཱཏྨན ཨཱཀརྵཎེན མནྡིརམཱགཏྱ ཏཾ ཀྲོཌེ ནིདྷཱཡ ཨཱིཤྭརསྱ དྷནྱཝཱདཾ ཀྲྀཏྭཱ ཀཐཡཱམཱས, ཡཐཱ,
29 “Olúwa Olódùmarè, nígbà yìí ni ó tó jọ̀wọ́ ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ lọ́wọ́ lọ, ní àlàáfíà, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
ཧེ པྲབྷོ ཏཝ དཱསོཡཾ ནིཛཝཱཀྱཱནུསཱརཏཿ། ཨིདཱནཱིནྟུ སཀལྱཱཎོ བྷཝཏཱ སཾཝིསྲྀཛྱཏཱམ྄།
30 Nítorí tí ojú mi ti rí ìgbàlà rẹ ná,
ཡཏཿ སཀལདེཤསྱ དཱིཔྟཡེ དཱིཔྟིརཱུཔཀཾ།
31 tí ìwọ ti pèsè sílẹ̀ níwájú ènìyàn gbogbo;
ཨིསྲཱཡེལཱིཡལོཀསྱ མཧཱགཽརཝརཱུཔཀཾ།
32 ìmọ́lẹ̀ láti mọ́ sí àwọn aláìkọlà, àti ògo Israẹli ènìyàn rẹ̀.”
ཡཾ ཏྲཱཡཀཾ ཛནཱནཱནྟུ སམྨུཁེ ཏྭམཛཱིཛནཿ། སཨེཝ ཝིདྱཏེ྅སྨཱཀཾ དྷྲཝཾ ནཡནནགོཙརེ༎
33 Ẹnu sì ya Josẹfu àti ìyá rẹ̀ sí nǹkan tí a ń sọ sí i wọ̀nyí.
ཏདཱནཱིཾ ཏེནོཀྟཱ ཨེཏཱཿ སཀལཱཿ ཀཐཱཿ ཤྲུཏྭཱ ཏསྱ མཱཏཱ ཡཱུཥཕ྄ ཙ ཝིསྨཡཾ མེནཱཏེ།
34 Simeoni sì súre fún wọn, ó sì wí fún Maria ìyá rẹ̀ pé, “Kíyèsi i, a gbé ọmọ yìí kalẹ̀ fún ìṣubú àti ìdìde ọ̀pọ̀ ènìyàn ní Israẹli; àti fún àmì tí a ń sọ̀rọ̀-òdì sí;
ཏཏཿ པརཾ ཤིམིཡོན྄ ཏེབྷྱ ཨཱཤིཥཾ དཏྟྭཱ ཏནྨཱཏརཾ མརིཡམམ྄ ཨུཝཱཙ, པཤྱ ཨིསྲཱཡེལོ ཝཾཤམདྷྱེ བཧཱུནཱཾ པཱཏནཱཡོཏྠཱཔནཱཡ ཙ ཏཐཱ ཝིརོདྷཔཱཏྲཾ བྷཝིཏུཾ, བཧཱུནཱཾ གུཔྟམནོགཏཱནཱཾ པྲཀཊཱིཀརཎཱཡ བཱལཀོཡཾ ནིཡུཀྟོསྟི།
35 (idà yóò sì gún ìwọ náà ní ọkàn pẹ̀lú) kí á lè fi ìrònú ọ̀pọ̀ ọkàn hàn.”
ཏསྨཱཏ྄ ཏཝཱཔི པྲཱཎཱཿ ཤཱུལེན ཝྱཏྶྱནྟེ།
36 Ẹnìkan sì ń bẹ, Anna wòlíì, ọmọbìnrin Penueli, nínú ẹ̀yà Aṣeri: ọjọ́ ogbó rẹ̀ pọ̀, ó ti bá ọkọ gbé ní ọdún méje láti ìgbà wúńdíá rẹ̀ wá;
ཨཔརཉྩ ཨཱཤེརསྱ ཝཾཤཱིཡཕིནཱུཡེལོ དུཧིཏཱ ཧནྣཱཁྱཱ ཨཏིཛརཏཱི བྷཝིཥྱདྭཱདིནྱེཀཱ ཡཱ ཝིཝཱཧཱཏ྄ པརཾ སཔྟ ཝཏྶརཱན྄ པཏྱཱ སཧ ནྱཝསཏ྄ ཏཏོ ཝིདྷཝཱ བྷཱུཏྭཱ ཙཏུརཤཱིཏིཝརྵཝཡཿཔཪྻྱནཏཾ
37 Ó sì ṣe opó títí ó fi di ẹni ọdún mẹ́rìnlélọ́gọ́rin, ẹni tí kò kúrò ní tẹmpili, ṣùgbọ́n ó ń fi àwẹ̀ àti àdúrà sin Ọlọ́run lọ́sàn án àti lóru.
མནྡིརེ སྠིཏྭཱ པྲཱརྠནོཔཝཱསཻརྡིཝཱནིཤམ྄ ཨཱིཤྭརམ྄ ཨསེཝཏ སཱཔི སྟྲཱི ཏསྨིན྄ སམཡེ མནྡིརམཱགཏྱ
38 Ó sì wólẹ̀ ní àkókò náà, ó sì dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run pẹ̀lú, ó sì sọ̀rọ̀ rẹ̀ fún gbogbo àwọn tí ó ń retí ìdáǹdè Jerusalẹmu.
པརམེཤྭརསྱ དྷནྱཝཱདཾ ཙཀཱར, ཡིརཱུཤཱལམྤུརཝཱསིནོ ཡཱཝནྟོ ལོཀཱ མུཀྟིམཔེཀྵྱ སྠིཏཱསྟཱན྄ ཡཱིཤོཪྻྲྀཏྟཱནྟཾ ཛྙཱཔཡཱམཱས།
39 Nígbà tí wọ́n sì ti ṣe nǹkan gbogbo tán gẹ́gẹ́ bí òfin Olúwa, wọ́n padà lọ sí Galili, sí Nasareti ìlú wọn.
ཨིཏྠཾ པརམེཤྭརསྱ ཝྱཝསྠཱནུསཱརེཎ སཪྻྭེཥུ ཀརྨྨསུ ཀྲྀཏེཥུ ཏཽ པུནཤྩ གཱལཱིལོ ནཱསརཏྣཱམཀཾ ནིཛནགརཾ པྲཏསྠཱཏེ།
40 Ọmọ náà sì ń dàgbà, ó sì ń lágbára, ó sì kún fún ọgbọ́n: oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run sì ń bẹ lára rẹ̀.
ཏཏྤཤྩཱད྄ བཱལཀཿ ཤརཱིརེཎ ཝྲྀདྡྷིམེཏྱ ཛྙཱནེན པརིཔཱུརྞ ཨཱཏྨནཱ ཤཀྟིམཱཾཤྩ བྷཝིཏུམཱརེབྷེ ཏཐཱ ཏསྨིན྄ ཨཱིཤྭརཱནུགྲཧོ བབྷཱུཝ།
41 Àwọn òbí rẹ̀ a sì máa lọ sí Jerusalẹmu ní ọdọọdún sí àjọ ìrékọjá.
ཏསྱ པིཏཱ མཱཏཱ ཙ པྲཏིཝརྵཾ ནིསྟཱརོཏྶཝསམཡེ ཡིརཱུཤཱལམམ྄ ཨགཙྪཏཱམ྄།
42 Nígbà tí ó sì di ọmọ ọdún méjìlá, wọ́n gòkè lọ sí Jerusalẹmu gẹ́gẹ́ bí ìṣe àjọ náà.
ཨཔརཉྩ ཡཱིཤཽ དྭཱདཤཝརྵཝཡསྐེ སཏི ཏཽ པཪྻྭསམཡསྱ རཱིཏྱནུསཱརེཎ ཡིརཱུཤཱལམཾ གཏྭཱ
43 Nígbà tí ọjọ́ wọn sì pé bí wọ́n ti ń padà bọ̀, ọmọ náà, Jesu dúró lẹ́yìn ní Jerusalẹmu; Josẹfu àti ìyá rẹ̀ kò mọ̀.
པཱཪྻྭཎཾ སམྤཱདྱ པུནརཔི ཝྱཱགྷུཡྻ ཡཱཏཿ ཀིནྟུ ཡཱིཤུརྦཱལཀོ ཡིརཱུཤཱལམི ཏིཥྛཏི། ཡཱུཥཕ྄ ཏནྨཱཏཱ ཙ ཏད྄ ཨཝིདིཏྭཱ
44 Ṣùgbọ́n wọ́n ṣe bí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ èrò, wọ́n rin ìrìn ọjọ́ kan; wọ́n wá a kiri nínú àwọn ará àti àwọn ojúlùmọ̀ wọn.
ས སངྒིབྷིཿ སཧ ཝིདྱཏ ཨེཏཙྩ བུདྭྭཱ དིནཻཀགམྱམཱརྒཾ ཛགྨཏུཿ། ཀིནྟུ ཤེཥེ ཛྙཱཏིབནྡྷཱུནཱཾ སམཱིཔེ མྲྀགཡིཏྭཱ ཏདུདྡེཤམཔྲཱཔྱ
45 Nígbà tí wọn kò sì rí i, wọ́n padà sí Jerusalẹmu, wọ́n ń wá a kiri.
ཏཽ པུནརཔི ཡིརཱུཤཱལམམ྄ པརཱཝྲྀཏྱཱགཏྱ ཏཾ མྲྀགཡཱཉྩཀྲཏུཿ།
46 Ó sì ṣe, lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́ta wọ́n rí i nínú tẹmpili ó jókòó ní àárín àwọn olùkọ́ni, ó ń gbọ́ tiwọn, ó sì ń bi wọ́n léèrè.
ཨཐ དིནཏྲཡཱཏ྄ པརཾ པཎྜིཏཱནཱཾ མདྷྱེ ཏེཥཱཾ ཀཐཱཿ ཤྲྀཎྭན྄ ཏཏྟྭཾ པྲྀཙྪཾཤྩ མནྡིརེ སམུཔཝིཥྚཿ ས ཏཱབྷྱཱཾ དྲྀཥྚཿ།
47 Ẹnu sì ya gbogbo àwọn tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀ fún òye àti ìdáhùn rẹ̀.
ཏདཱ ཏསྱ བུདྡྷྱཱ པྲཏྱུཏྟརཻཤྩ སཪྻྭེ ཤྲོཏཱརོ ཝིསྨཡམཱཔདྱནྟེ།
48 Nígbà tí wọ́n sì rí i, háà ṣe wọ́n, ìyá rẹ̀ sì bi í pé, “Ọmọ, èéṣe tí ìwọ fi ṣe wá bẹ́ẹ̀? Sá wò ó, baba rẹ̀ àti èmi ti ń fi ìbànújẹ́ wá ọ kiri.”
ཏཱདྲྀཤཾ དྲྀཥྚྭཱ ཏསྱ ཛནཀོ ཛནནཱི ཙ ཙམཙྩཀྲཏུཿ ཀིཉྩ ཏསྱ མཱཏཱ ཏམཝདཏ྄, ཧེ པུཏྲ, ཀཐམཱཝཱཾ པྲཏཱིཏྠཾ སམཱཙརསྟྭམ྄? པཤྱ ཏཝ པིཏཱཧཉྩ ཤོཀཱཀུལཽ སནྟཽ ཏྭཱམནྭིཙྪཱཝཿ སྨ།
49 Ó sì dáhùn wí fún wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń wá mi kiri? Ẹ̀yin kò mọ̀ pé èmi kò lè ṣàìmá wà níbi iṣẹ́ Baba mi?”
ཏཏཿ སོཝདཏ྄ ཀུཏོ མཱམ྄ ཨནྭཻཙྪཏཾ? པིཏུརྒྲྀཧེ མཡཱ སྠཱཏཝྱམ྄ ཨེཏཏ྄ ཀིཾ ཡུཝཱབྷྱཱཾ ན ཛྙཱཡཏེ?
50 Ọ̀rọ̀ tí o sọ kò sì yé wọn.
ཀིནྟུ ཏཽ ཏསྱཻཏདྭཱཀྱསྱ ཏཱཏྤཪྻྱཾ བོདྡྷུཾ ནཱཤཀྣུཏཱཾ།
51 Ó sì bá wọn sọ̀kalẹ̀ lọ sí Nasareti, sì fi ara balẹ̀ fún wọn, ṣùgbọ́n ìyá rẹ̀ pa gbogbo nǹkan wọ̀nyí mọ́ nínú ọkàn rẹ̀.
ཏཏཿ པརཾ ས ཏཱབྷྱཱཾ སཧ ནཱསརཏཾ གཏྭཱ ཏཡོཪྻཤཱིབྷཱུཏསྟསྠཽ ཀིནྟུ སཪྻྭཱ ཨེཏཱཿ ཀཐཱསྟསྱ མཱཏཱ མནསི སྠཱཔཡཱམཱས།
52 Jesu sì ń pọ̀ ní ọgbọ́n, sì ń dàgbà, ó sì wà ní ojúrere ní ọ̀dọ̀ Ọlọ́run àti ènìyàn.
ཨཐ ཡཱིཤོ རྦུདྡྷིཿ ཤརཱིརཉྩ ཏཐཱ ཏསྨིན྄ ཨཱིཤྭརསྱ མཱནཝཱནཱཉྩཱནུགྲཧོ ཝརྡྡྷིཏུམ྄ ཨཱརེབྷེ།