< Luke 2 >
1 Ó sì ṣe ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àṣẹ ti ọ̀dọ̀ Kesari Augustu jáde wá pé, kí a kọ orúkọ gbogbo ayé sínú ìwé.
aparañca tasmin kāle rājyasya sarvveṣāṁ lokānāṁ nāmāni lekhayitum agastakaisara ājñāpayāmāsa|
2 (Èyí ni ìkọ sínú ìwé èkínní tí a ṣe nígbà tí Kirene fi jẹ baálẹ̀ Siria.)
tadanusāreṇa kurīṇiyanāmani suriyādeśasya śāsake sati nāmalekhanaṁ prārebhe|
3 Gbogbo àwọn ènìyàn sì lọ láti kọ orúkọ wọn sínú ìwé, olúkúlùkù sí ìlú ara rẹ̀.
ato heto rnāma lekhituṁ sarvve janāḥ svīyaṁ svīyaṁ nagaraṁ jagmuḥ|
4 Josẹfu pẹ̀lú sì gòkè láti Nasareti ni Galili, sí ìlú Dafidi ní Judea, tí à ń pè ní Bẹtilẹhẹmu; nítorí ti ìran àti ìdílé Dafidi ní í ṣe,
tadānīṁ yūṣaph nāma lekhituṁ vāgdattayā svabhāryyayā garbbhavatyā mariyamā saha svayaṁ dāyūdaḥ sajātivaṁśa iti kāraṇād gālīlpradeśasya nāsaratnagarād
5 láti kọ orúkọ rẹ̀, pẹ̀lú Maria aya rẹ̀ àfẹ́sọ́nà, tí oyún rẹ̀ ti tó bí.
yihūdāpradeśasya baitlehamākhyaṁ dāyūdnagaraṁ jagāma|
6 Ó sì ṣe, nígbà tí wọ́n wà níbẹ̀, ọjọ́ rẹ̀ pé tí òun yóò bí.
anyacca tatra sthāne tayostiṣṭhatoḥ sato rmariyamaḥ prasūtikāla upasthite
7 Ó sì bí àkọ́bí rẹ̀ ọmọkùnrin, ó sì fi ọ̀já wé e, ó sì tẹ́ ẹ sínú ibùjẹ ẹran; nítorí tí ààyè kò sí fún wọn nínú ilé èrò.
sā taṁ prathamasutaṁ prāsoṣṭa kintu tasmin vāsagṛhe sthānābhāvād bālakaṁ vastreṇa veṣṭayitvā gośālāyāṁ sthāpayāmāsa|
8 Àwọn olùṣọ́-àgùntàn ń bẹ tí wọ́n ń gbé ní ìlú náà, wọ́n ń ṣọ́ agbo àgùntàn wọn ní òru ní pápá tí wọ́n ń gbé.
anantaraṁ ye kiyanto meṣapālakāḥ svameṣavrajarakṣāyai tatpradeśe sthitvā rajanyāṁ prāntare prahariṇaḥ karmma kurvvanti,
9 Angẹli Olúwa sì yọ sí wọn, ògo Olúwa sì ràn yí wọn ká, ẹ̀rù sì bà wọ́n gidigidi.
teṣāṁ samīpaṁ parameśvarasya dūta āgatyopatasthau; tadā catuṣpārśve parameśvarasya tejasaḥ prakāśitatvāt te'tiśaśaṅkire|
10 Angẹli náà sì wí fún wọn pé, “Má bẹ̀rù: sá wò ó, mo mú ìyìnrere ayọ̀ ńlá fún yín wá, tí yóò ṣe ti ènìyàn gbogbo.
tadā sa dūta uvāca mā bhaiṣṭa paśyatādya dāyūdaḥ pure yuṣmannimittaṁ trātā prabhuḥ khrīṣṭo'janiṣṭa,
11 Nítorí a ti bí Olùgbàlà fún yín lónìí ní ìlú Dafidi, tí í ṣe Kristi Olúwa.
sarvveṣāṁ lokānāṁ mahānandajanakam imaṁ maṅgalavṛttāntaṁ yuṣmān jñāpayāmi|
12 Èyí ni yóò sì ṣe àmì fún yín; ẹ̀yin yóò rí ọmọ ọwọ́ tí a fi ọ̀já wé, ó dùbúlẹ̀ ní ibùjẹ ẹran.”
yūyaṁ (tatsthānaṁ gatvā) vastraveṣṭitaṁ taṁ bālakaṁ gośālāyāṁ śayanaṁ drakṣyatha yuṣmān pratīdaṁ cihnaṁ bhaviṣyati|
13 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ogun ọ̀run sì darapọ̀ mọ́ angẹli náà ní òjijì, wọ́n ń yin Ọlọ́run, wí pé,
dūta imāṁ kathāṁ kathitavati tatrākasmāt svargīyāḥ pṛtanā āgatya kathām imāṁ kathayitveśvarasya guṇānanvavādiṣuḥ, yathā,
14 “Ògo ni fún Ọlọ́run lókè ọ̀run, àti ní ayé àlàáfíà, ìfẹ́ inú rere sí ènìyàn.”
sarvvordvvasthairīśvarasya mahimā samprakāśyatāṁ| śāntirbhūyāt pṛthivyāstu santoṣaśca narān prati||
15 Ó sì ṣe, nígbà tí àwọn angẹli náà padà kúrò lọ́dọ̀ wọn lọ sí ọ̀run, àwọn olùṣọ́-àgùntàn náà bá ara wọn sọ pé, “Ẹ jẹ́ kí á lọ tààrà sí Bẹtilẹhẹmu, kí á lè rí ohun tí ó ṣẹ̀, tí Olúwa fihàn fún wa.”
tataḥ paraṁ teṣāṁ sannidhe rdūtagaṇe svargaṁ gate meṣapālakāḥ parasparam avecan āgacchata prabhuḥ parameśvaro yāṁ ghaṭanāṁ jñāpitavān tasyā yātharyaṁ jñātuṁ vayamadhunā baitlehampuraṁ yāmaḥ|
16 Wọ́n sì wá lọ́gán, wọ́n sì rí Maria àti Josẹfu, àti ọmọ ọwọ́ náà, ó dùbúlẹ̀ nínú ibùjẹ ẹran.
paścāt te tūrṇaṁ vrajitvā mariyamaṁ yūṣaphaṁ gośālāyāṁ śayanaṁ bālakañca dadṛśuḥ|
17 Nígbà tí wọ́n sì ti rí i, wọ́n sọ ohun tí a ti wí fún wọn nípa ti ọmọ yìí.
itthaṁ dṛṣṭvā bālakasyārthe proktāṁ sarvvakathāṁ te prācārayāñcakruḥ|
18 Ẹnu sì ya gbogbo àwọn tí ó gbọ́ sí nǹkan wọ̀nyí tí a ti wí fún wọn láti ọ̀dọ̀ àwọn olùṣọ́-àgùntàn wá.
tato ye lokā meṣarakṣakāṇāṁ vadanebhyastāṁ vārttāṁ śuśruvuste mahāścaryyaṁ menire|
19 Ṣùgbọ́n Maria pa gbogbo nǹkan wọ̀nyí mọ́, ó ń rò wọ́n nínú ọkàn rẹ̀.
kintu mariyam etatsarvvaghaṭanānāṁ tātparyyaṁ vivicya manasi sthāpayāmāsa|
20 Àwọn olùṣọ́-àgùntàn sì padà lọ, wọ́n ń fi ògo fún Ọlọ́run, wọ́n sì yìn ín, nítorí ohun gbogbo tí wọ́n ti gbọ́ àti tí wọ́n ti rí, bí a ti wí i fún wọn.
tatpaścād dūtavijñaptānurūpaṁ śrutvā dṛṣṭvā ca meṣapālakā īśvarasya guṇānuvādaṁ dhanyavādañca kurvvāṇāḥ parāvṛtya yayuḥ|
21 Nígbà tí ọjọ́ mẹ́jọ sì pé láti kọ ọmọ náà nílà, wọ́n pe orúkọ rẹ̀ ní Jesu, bí a ti sọ ọ́ tẹ́lẹ̀ láti ọ̀dọ̀ angẹli náà wá kí á tó lóyún rẹ̀.
atha bālakasya tvakchedanakāle'ṣṭamadivase samupasthite tasya garbbhasthiteḥ purvvaṁ svargīyadūto yathājñāpayat tadanurūpaṁ te tannāmadheyaṁ yīśuriti cakrire|
22 Nígbà tí ọjọ́ ìwẹ̀nù Maria sì pé gẹ́gẹ́ bí òfin Mose, Josẹfu àti Maria gbé Jesu wá sí Jerusalẹmu láti fi í fún Olúwa
tataḥ paraṁ mūsālikhitavyavasthāyā anusāreṇa mariyamaḥ śucitvakāla upasthite,
23 (bí a ti kọ ọ́ sínú òfin Olúwa pé, “Gbogbo ọmọ ọkùnrin tí ó ṣe àkọ́bí, òun ni a ó pè ní mímọ́ fún Olúwa”),
"prathamajaḥ sarvvaḥ puruṣasantānaḥ parameśvare samarpyatāṁ," iti parameśvarasya vyavasthayā
24 àti láti rú ẹbọ gẹ́gẹ́ bí èyí tí a wí nínú òfin Olúwa: “Àdàbà méjì tàbí ọmọ ẹyẹlé méjì.”
yīśuṁ parameśvare samarpayitum śāstrīyavidhyuktaṁ kapotadvayaṁ pārāvataśāvakadvayaṁ vā baliṁ dātuṁ te taṁ gṛhītvā yirūśālamam āyayuḥ|
25 Sì kíyèsi i, ọkùnrin kan wà ní Jerusalẹmu, orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Simeoni; ọkùnrin náà sì ṣe olóòtítọ́ àti olùfọkànsìn, ó ń retí ìtùnú Israẹli, Ẹ̀mí mímọ́ sì bà lé e.
yirūśālampuranivāsī śimiyonnāmā dhārmmika eka āsīt sa isrāyelaḥ sāntvanāmapekṣya tasthau kiñca pavitra ātmā tasminnāvirbhūtaḥ|
26 A sì ti fihàn án láti ọ̀dọ̀ Ẹ̀mí Mímọ́ náà wá pé, òun kì yóò rí ikú, kí ó tó rí Kristi Olúwa.
aparaṁ prabhuṇā parameśvareṇābhiṣikte trātari tvayā na dṛṣṭe tvaṁ na mariṣyasīti vākyaṁ pavitreṇa ātmanā tasma prākathyata|
27 Ó sì ti ipa Ẹ̀mí wá sínú tẹmpili. Nígbà tí àwọn òbí rẹ̀ sì gbé Jesu wá, láti ṣe fún un bí ìṣe òfin.
aparañca yadā yīśoḥ pitā mātā ca tadarthaṁ vyavasthānurūpaṁ karmma karttuṁ taṁ mandiram āninyatustadā
28 Nígbà náà ni Simeoni gbé e ní apá rẹ̀, ó fi ìbùkún fún Ọlọ́run, ó ní:
śimiyon ātmana ākarṣaṇena mandiramāgatya taṁ kroḍe nidhāya īśvarasya dhanyavādaṁ kṛtvā kathayāmāsa, yathā,
29 “Olúwa Olódùmarè, nígbà yìí ni ó tó jọ̀wọ́ ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ lọ́wọ́ lọ, ní àlàáfíà, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
he prabho tava dāsoyaṁ nijavākyānusārataḥ| idānīntu sakalyāṇo bhavatā saṁvisṛjyatām|
30 Nítorí tí ojú mi ti rí ìgbàlà rẹ ná,
yataḥ sakaladeśasya dīptaye dīptirūpakaṁ|
31 tí ìwọ ti pèsè sílẹ̀ níwájú ènìyàn gbogbo;
isrāyelīyalokasya mahāgauravarūpakaṁ|
32 ìmọ́lẹ̀ láti mọ́ sí àwọn aláìkọlà, àti ògo Israẹli ènìyàn rẹ̀.”
yaṁ trāyakaṁ janānāntu sammukhe tvamajījanaḥ| saeva vidyate'smākaṁ dhravaṁ nayananagocare||
33 Ẹnu sì ya Josẹfu àti ìyá rẹ̀ sí nǹkan tí a ń sọ sí i wọ̀nyí.
tadānīṁ tenoktā etāḥ sakalāḥ kathāḥ śrutvā tasya mātā yūṣaph ca vismayaṁ menāte|
34 Simeoni sì súre fún wọn, ó sì wí fún Maria ìyá rẹ̀ pé, “Kíyèsi i, a gbé ọmọ yìí kalẹ̀ fún ìṣubú àti ìdìde ọ̀pọ̀ ènìyàn ní Israẹli; àti fún àmì tí a ń sọ̀rọ̀-òdì sí;
tataḥ paraṁ śimiyon tebhya āśiṣaṁ dattvā tanmātaraṁ mariyamam uvāca, paśya isrāyelo vaṁśamadhye bahūnāṁ pātanāyotthāpanāya ca tathā virodhapātraṁ bhavituṁ, bahūnāṁ guptamanogatānāṁ prakaṭīkaraṇāya bālakoyaṁ niyuktosti|
35 (idà yóò sì gún ìwọ náà ní ọkàn pẹ̀lú) kí á lè fi ìrònú ọ̀pọ̀ ọkàn hàn.”
tasmāt tavāpi prāṇāḥ śūlena vyatsyante|
36 Ẹnìkan sì ń bẹ, Anna wòlíì, ọmọbìnrin Penueli, nínú ẹ̀yà Aṣeri: ọjọ́ ogbó rẹ̀ pọ̀, ó ti bá ọkọ gbé ní ọdún méje láti ìgbà wúńdíá rẹ̀ wá;
aparañca āśerasya vaṁśīyaphinūyelo duhitā hannākhyā atijaratī bhaviṣyadvādinyekā yā vivāhāt paraṁ sapta vatsarān patyā saha nyavasat tato vidhavā bhūtvā caturaśītivarṣavayaḥparyyanataṁ
37 Ó sì ṣe opó títí ó fi di ẹni ọdún mẹ́rìnlélọ́gọ́rin, ẹni tí kò kúrò ní tẹmpili, ṣùgbọ́n ó ń fi àwẹ̀ àti àdúrà sin Ọlọ́run lọ́sàn án àti lóru.
mandire sthitvā prārthanopavāsairdivāniśam īśvaram asevata sāpi strī tasmin samaye mandiramāgatya
38 Ó sì wólẹ̀ ní àkókò náà, ó sì dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run pẹ̀lú, ó sì sọ̀rọ̀ rẹ̀ fún gbogbo àwọn tí ó ń retí ìdáǹdè Jerusalẹmu.
parameśvarasya dhanyavādaṁ cakāra, yirūśālampuravāsino yāvanto lokā muktimapekṣya sthitāstān yīśorvṛttāntaṁ jñāpayāmāsa|
39 Nígbà tí wọ́n sì ti ṣe nǹkan gbogbo tán gẹ́gẹ́ bí òfin Olúwa, wọ́n padà lọ sí Galili, sí Nasareti ìlú wọn.
itthaṁ parameśvarasya vyavasthānusāreṇa sarvveṣu karmmasu kṛteṣu tau punaśca gālīlo nāsaratnāmakaṁ nijanagaraṁ pratasthāte|
40 Ọmọ náà sì ń dàgbà, ó sì ń lágbára, ó sì kún fún ọgbọ́n: oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run sì ń bẹ lára rẹ̀.
tatpaścād bālakaḥ śarīreṇa vṛddhimetya jñānena paripūrṇa ātmanā śaktimāṁśca bhavitumārebhe tathā tasmin īśvarānugraho babhūva|
41 Àwọn òbí rẹ̀ a sì máa lọ sí Jerusalẹmu ní ọdọọdún sí àjọ ìrékọjá.
tasya pitā mātā ca prativarṣaṁ nistārotsavasamaye yirūśālamam agacchatām|
42 Nígbà tí ó sì di ọmọ ọdún méjìlá, wọ́n gòkè lọ sí Jerusalẹmu gẹ́gẹ́ bí ìṣe àjọ náà.
aparañca yīśau dvādaśavarṣavayaske sati tau parvvasamayasya rītyanusāreṇa yirūśālamaṁ gatvā
43 Nígbà tí ọjọ́ wọn sì pé bí wọ́n ti ń padà bọ̀, ọmọ náà, Jesu dúró lẹ́yìn ní Jerusalẹmu; Josẹfu àti ìyá rẹ̀ kò mọ̀.
pārvvaṇaṁ sampādya punarapi vyāghuyya yātaḥ kintu yīśurbālako yirūśālami tiṣṭhati| yūṣaph tanmātā ca tad aviditvā
44 Ṣùgbọ́n wọ́n ṣe bí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ èrò, wọ́n rin ìrìn ọjọ́ kan; wọ́n wá a kiri nínú àwọn ará àti àwọn ojúlùmọ̀ wọn.
sa saṅgibhiḥ saha vidyata etacca budvvā dinaikagamyamārgaṁ jagmatuḥ| kintu śeṣe jñātibandhūnāṁ samīpe mṛgayitvā taduddeśamaprāpya
45 Nígbà tí wọn kò sì rí i, wọ́n padà sí Jerusalẹmu, wọ́n ń wá a kiri.
tau punarapi yirūśālamam parāvṛtyāgatya taṁ mṛgayāñcakratuḥ|
46 Ó sì ṣe, lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́ta wọ́n rí i nínú tẹmpili ó jókòó ní àárín àwọn olùkọ́ni, ó ń gbọ́ tiwọn, ó sì ń bi wọ́n léèrè.
atha dinatrayāt paraṁ paṇḍitānāṁ madhye teṣāṁ kathāḥ śṛṇvan tattvaṁ pṛcchaṁśca mandire samupaviṣṭaḥ sa tābhyāṁ dṛṣṭaḥ|
47 Ẹnu sì ya gbogbo àwọn tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀ fún òye àti ìdáhùn rẹ̀.
tadā tasya buddhyā pratyuttaraiśca sarvve śrotāro vismayamāpadyante|
48 Nígbà tí wọ́n sì rí i, háà ṣe wọ́n, ìyá rẹ̀ sì bi í pé, “Ọmọ, èéṣe tí ìwọ fi ṣe wá bẹ́ẹ̀? Sá wò ó, baba rẹ̀ àti èmi ti ń fi ìbànújẹ́ wá ọ kiri.”
tādṛśaṁ dṛṣṭvā tasya janako jananī ca camaccakratuḥ kiñca tasya mātā tamavadat, he putra, kathamāvāṁ pratītthaṁ samācarastvam? paśya tava pitāhañca śokākulau santau tvāmanvicchāvaḥ sma|
49 Ó sì dáhùn wí fún wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń wá mi kiri? Ẹ̀yin kò mọ̀ pé èmi kò lè ṣàìmá wà níbi iṣẹ́ Baba mi?”
tataḥ sovadat kuto mām anvaicchataṁ? piturgṛhe mayā sthātavyam etat kiṁ yuvābhyāṁ na jñāyate?
50 Ọ̀rọ̀ tí o sọ kò sì yé wọn.
kintu tau tasyaitadvākyasya tātparyyaṁ boddhuṁ nāśaknutāṁ|
51 Ó sì bá wọn sọ̀kalẹ̀ lọ sí Nasareti, sì fi ara balẹ̀ fún wọn, ṣùgbọ́n ìyá rẹ̀ pa gbogbo nǹkan wọ̀nyí mọ́ nínú ọkàn rẹ̀.
tataḥ paraṁ sa tābhyāṁ saha nāsarataṁ gatvā tayorvaśībhūtastasthau kintu sarvvā etāḥ kathāstasya mātā manasi sthāpayāmāsa|
52 Jesu sì ń pọ̀ ní ọgbọ́n, sì ń dàgbà, ó sì wà ní ojúrere ní ọ̀dọ̀ Ọlọ́run àti ènìyàn.
atha yīśo rbuddhiḥ śarīrañca tathā tasmin īśvarasya mānavānāñcānugraho varddhitum ārebhe|