< Luke 2 >
1 Ó sì ṣe ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àṣẹ ti ọ̀dọ̀ Kesari Augustu jáde wá pé, kí a kọ orúkọ gbogbo ayé sínú ìwé.
I stało się w one dni, że wyszedł dekret od cesarza Augusta, aby popisano wszystek świat.
2 (Èyí ni ìkọ sínú ìwé èkínní tí a ṣe nígbà tí Kirene fi jẹ baálẹ̀ Siria.)
A ten popis pierwszy stał się, gdy Cyreneusz był starostą Syryjskim.
3 Gbogbo àwọn ènìyàn sì lọ láti kọ orúkọ wọn sínú ìwé, olúkúlùkù sí ìlú ara rẹ̀.
I szli wszyscy, aby popisani byli, każdy do miasta swego.
4 Josẹfu pẹ̀lú sì gòkè láti Nasareti ni Galili, sí ìlú Dafidi ní Judea, tí à ń pè ní Bẹtilẹhẹmu; nítorí ti ìran àti ìdílé Dafidi ní í ṣe,
Wstąpił też i Józef z Galilei z miasta Nazaretu do ziemi Judzkiej, do miasta Dawidowego, które zowią Betlehem, (przeto iż on był z domu i z familii Dawidowej; )
5 láti kọ orúkọ rẹ̀, pẹ̀lú Maria aya rẹ̀ àfẹ́sọ́nà, tí oyún rẹ̀ ti tó bí.
Aby był popisany z Maryją, poślubioną sobie małżonką, która była brzemienną.
6 Ó sì ṣe, nígbà tí wọ́n wà níbẹ̀, ọjọ́ rẹ̀ pé tí òun yóò bí.
I stało się, gdy tam byli, wypełniły się dni, aby porodziła.
7 Ó sì bí àkọ́bí rẹ̀ ọmọkùnrin, ó sì fi ọ̀já wé e, ó sì tẹ́ ẹ sínú ibùjẹ ẹran; nítorí tí ààyè kò sí fún wọn nínú ilé èrò.
I porodziła syna swego pierworodnego; a uwinęła go w pieluszki, i położyła go w żłobie, przeto iż miejsca nie mieli w gospodzie.
8 Àwọn olùṣọ́-àgùntàn ń bẹ tí wọ́n ń gbé ní ìlú náà, wọ́n ń ṣọ́ agbo àgùntàn wọn ní òru ní pápá tí wọ́n ń gbé.
A byli pasterze w onej krainie w polu nocujący i straż nocną trzymający nad stadem swojem.
9 Angẹli Olúwa sì yọ sí wọn, ògo Olúwa sì ràn yí wọn ká, ẹ̀rù sì bà wọ́n gidigidi.
A oto Anioł Pański stanął podle nich, a chwała Pańska zewsząd oświeciła je, i bali się bojaźnią wielką.
10 Angẹli náà sì wí fún wọn pé, “Má bẹ̀rù: sá wò ó, mo mú ìyìnrere ayọ̀ ńlá fún yín wá, tí yóò ṣe ti ènìyàn gbogbo.
I rzekł do nich Anioł: Nie bójcie się; bo oto zwiastuję wam radość wielką, która będzie wszystkiemu ludowi:
11 Nítorí a ti bí Olùgbàlà fún yín lónìí ní ìlú Dafidi, tí í ṣe Kristi Olúwa.
Iż się wam dziś narodził zbawiciel, który jest Chrystus Pan, w mieście Dawidowem.
12 Èyí ni yóò sì ṣe àmì fún yín; ẹ̀yin yóò rí ọmọ ọwọ́ tí a fi ọ̀já wé, ó dùbúlẹ̀ ní ibùjẹ ẹran.”
A to wam będzie za znak: znajdziecie niemowlątko uwinione w pieluszki, leżące w żłobie.
13 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ogun ọ̀run sì darapọ̀ mọ́ angẹli náà ní òjijì, wọ́n ń yin Ọlọ́run, wí pé,
A zaraz z onym Aniołem przybyło mnóstwo wojsk niebieskich, chwalących Boga i mówiących:
14 “Ògo ni fún Ọlọ́run lókè ọ̀run, àti ní ayé àlàáfíà, ìfẹ́ inú rere sí ènìyàn.”
Chwała na wysokościach Bogu, a na ziemi pokój, w ludziach dobre upodobanie.
15 Ó sì ṣe, nígbà tí àwọn angẹli náà padà kúrò lọ́dọ̀ wọn lọ sí ọ̀run, àwọn olùṣọ́-àgùntàn náà bá ara wọn sọ pé, “Ẹ jẹ́ kí á lọ tààrà sí Bẹtilẹhẹmu, kí á lè rí ohun tí ó ṣẹ̀, tí Olúwa fihàn fún wa.”
I stało się, gdy odeszli Aniołowie od nich do nieba, że oniż pasterze rzekli jedni do drugich: Pójdźmyż aż do Betlehemu, a oglądajmy tę rzecz, która się stała, którą nam Pan oznajmił.
16 Wọ́n sì wá lọ́gán, wọ́n sì rí Maria àti Josẹfu, àti ọmọ ọwọ́ náà, ó dùbúlẹ̀ nínú ibùjẹ ẹran.
A tak spiesząc się, przyszli i znaleźli Maryję i Józefa, i ono niemowlątko leżące w żłobie.
17 Nígbà tí wọ́n sì ti rí i, wọ́n sọ ohun tí a ti wí fún wọn nípa ti ọmọ yìí.
I ujrzawszy rozsławili to, co im było powiedziano o tem dzieciątku.
18 Ẹnu sì ya gbogbo àwọn tí ó gbọ́ sí nǹkan wọ̀nyí tí a ti wí fún wọn láti ọ̀dọ̀ àwọn olùṣọ́-àgùntàn wá.
A wszyscy, którzy słyszeli, dziwowali się temu, co im pasterze powiadali.
19 Ṣùgbọ́n Maria pa gbogbo nǹkan wọ̀nyí mọ́, ó ń rò wọ́n nínú ọkàn rẹ̀.
Lecz Maryja zachowywała wszystkie te słowa, uważając je w sercu swojem.
20 Àwọn olùṣọ́-àgùntàn sì padà lọ, wọ́n ń fi ògo fún Ọlọ́run, wọ́n sì yìn ín, nítorí ohun gbogbo tí wọ́n ti gbọ́ àti tí wọ́n ti rí, bí a ti wí i fún wọn.
I wrócili się pasterze, wielbiąc i chwaląc Boga ze wszystkiego, co słyszeli i widzieli, tak jako im było powiedziano.
21 Nígbà tí ọjọ́ mẹ́jọ sì pé láti kọ ọmọ náà nílà, wọ́n pe orúkọ rẹ̀ ní Jesu, bí a ti sọ ọ́ tẹ́lẹ̀ láti ọ̀dọ̀ angẹli náà wá kí á tó lóyún rẹ̀.
A gdy się wypełniło ośm dni, aby obrzezano ono dzieciątko, tedy imię jego nazwane jest Jezus, którem było nazwane od Anioła, pierwej niż się w żywocie poczęło.
22 Nígbà tí ọjọ́ ìwẹ̀nù Maria sì pé gẹ́gẹ́ bí òfin Mose, Josẹfu àti Maria gbé Jesu wá sí Jerusalẹmu láti fi í fún Olúwa
Gdy się też wypełniły dni oczyszczenia jej według zakonu Mojżeszowego, przynieśli go do Jeruzalemu, aby go stawili Panu,
23 (bí a ti kọ ọ́ sínú òfin Olúwa pé, “Gbogbo ọmọ ọkùnrin tí ó ṣe àkọ́bí, òun ni a ó pè ní mímọ́ fún Olúwa”),
(Tak jako napisano w zakonie Pańskim: że wszelki mężczyzna, otwierający żywot, świętym Panu nazwany będzie.)
24 àti láti rú ẹbọ gẹ́gẹ́ bí èyí tí a wí nínú òfin Olúwa: “Àdàbà méjì tàbí ọmọ ẹyẹlé méjì.”
A żeby oddali ofiarę według tego, co powiedziano w zakonie Pańskim, parę synogarlic, albo dwoje gołąbiąt.
25 Sì kíyèsi i, ọkùnrin kan wà ní Jerusalẹmu, orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Simeoni; ọkùnrin náà sì ṣe olóòtítọ́ àti olùfọkànsìn, ó ń retí ìtùnú Israẹli, Ẹ̀mí mímọ́ sì bà lé e.
A oto był człowiek w Jeruzalemie, któremu imię było Symeon; a ten człowiek był sprawiedliwy i bogobojny, oczekujący pociechy Izraelskiej, a Duch Święty był nad nim.
26 A sì ti fihàn án láti ọ̀dọ̀ Ẹ̀mí Mímọ́ náà wá pé, òun kì yóò rí ikú, kí ó tó rí Kristi Olúwa.
I obwieszczony był od Boga przez Ducha Świętego, że nie miał oglądać śmierci, ażby pierwej oglądał Chrystusa Pańskiego.
27 Ó sì ti ipa Ẹ̀mí wá sínú tẹmpili. Nígbà tí àwọn òbí rẹ̀ sì gbé Jesu wá, láti ṣe fún un bí ìṣe òfin.
Ten przyszedł z natchnienia Ducha Świętego do kościoła; a gdy rodzice wnosili dzieciątko, Jezusa, aby uczynili według zwyczaju zakonnego przy nim.
28 Nígbà náà ni Simeoni gbé e ní apá rẹ̀, ó fi ìbùkún fún Ọlọ́run, ó ní:
Tedy on wziąwszy go na ręce swoje, chwalił Boga i mówił:
29 “Olúwa Olódùmarè, nígbà yìí ni ó tó jọ̀wọ́ ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ lọ́wọ́ lọ, ní àlàáfíà, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Teraz puszczasz sługę twego, Panie! według słowa twego, w pokoju:
30 Nítorí tí ojú mi ti rí ìgbàlà rẹ ná,
Gdyż oczy moje oglądały zbawienie twoje,
31 tí ìwọ ti pèsè sílẹ̀ níwájú ènìyàn gbogbo;
Któreś zgotował przed obliczem wszystkich ludzi;
32 ìmọ́lẹ̀ láti mọ́ sí àwọn aláìkọlà, àti ògo Israẹli ènìyàn rẹ̀.”
Światłość ku objawieniu poganom, a chwałę ludu twego Izraelskiego.
33 Ẹnu sì ya Josẹfu àti ìyá rẹ̀ sí nǹkan tí a ń sọ sí i wọ̀nyí.
A ojciec i matka jego dziwowali się temu, co powiadano o nim.
34 Simeoni sì súre fún wọn, ó sì wí fún Maria ìyá rẹ̀ pé, “Kíyèsi i, a gbé ọmọ yìí kalẹ̀ fún ìṣubú àti ìdìde ọ̀pọ̀ ènìyàn ní Israẹli; àti fún àmì tí a ń sọ̀rọ̀-òdì sí;
I błogosławił im Symeon, i rzekł do Maryi, matki jego: Oto ten położony jest na upadek i na powstanie wielu ich w Izraelu, i na znak, przeciw któremu mówić będą.
35 (idà yóò sì gún ìwọ náà ní ọkàn pẹ̀lú) kí á lè fi ìrònú ọ̀pọ̀ ọkàn hàn.”
(I twoję własną duszę miecz przeniknie, ) aby myśli z wielu serc objawione były.
36 Ẹnìkan sì ń bẹ, Anna wòlíì, ọmọbìnrin Penueli, nínú ẹ̀yà Aṣeri: ọjọ́ ogbó rẹ̀ pọ̀, ó ti bá ọkọ gbé ní ọdún méje láti ìgbà wúńdíá rẹ̀ wá;
A była Anna prorokini, córka Fanuelowa, z pokolenia Asser, która była bardzo podeszła w latach, i żyła siedm lat z mężem od panieństwa swego.
37 Ó sì ṣe opó títí ó fi di ẹni ọdún mẹ́rìnlélọ́gọ́rin, ẹni tí kò kúrò ní tẹmpili, ṣùgbọ́n ó ń fi àwẹ̀ àti àdúrà sin Ọlọ́run lọ́sàn án àti lóru.
A ta była wdową, około ośmdziesiąt i czterech lat; która nie wychodziła z kościoła, w postach i w modlitwach służąc Bogu w nocy i we dnie.
38 Ó sì wólẹ̀ ní àkókò náà, ó sì dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run pẹ̀lú, ó sì sọ̀rọ̀ rẹ̀ fún gbogbo àwọn tí ó ń retí ìdáǹdè Jerusalẹmu.
Ta też onejże godziny nadszedłszy, wyznawała Pana, i mówiła o nim wszystkim, którzy oczekiwali odkupienia w Jeruzalemie.
39 Nígbà tí wọ́n sì ti ṣe nǹkan gbogbo tán gẹ́gẹ́ bí òfin Olúwa, wọ́n padà lọ sí Galili, sí Nasareti ìlú wọn.
A tak wykonawszy wszystko według zakonu Pańskiego, wrócili się do Galilei, do miasta swego Nazaretu.
40 Ọmọ náà sì ń dàgbà, ó sì ń lágbára, ó sì kún fún ọgbọ́n: oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run sì ń bẹ lára rẹ̀.
A dzieciątko ono rosło, i umacniało się w Duchu, pełne będąc mądrości, a łaska Boża była nad niem.
41 Àwọn òbí rẹ̀ a sì máa lọ sí Jerusalẹmu ní ọdọọdún sí àjọ ìrékọjá.
A rodzice jego chadzali na każdy rok do Jeruzalemu na święto wielkanocne.
42 Nígbà tí ó sì di ọmọ ọdún méjìlá, wọ́n gòkè lọ sí Jerusalẹmu gẹ́gẹ́ bí ìṣe àjọ náà.
A gdy już był we dwunastym roku, a oni wstępowali do Jeruzalemu według zwyczaju onego święta;
43 Nígbà tí ọjọ́ wọn sì pé bí wọ́n ti ń padà bọ̀, ọmọ náà, Jesu dúró lẹ́yìn ní Jerusalẹmu; Josẹfu àti ìyá rẹ̀ kò mọ̀.
I gdy skończyli one dni, a już się wracali nazad, zostało dziecię Jezus w Jeruzalemie, a tego nie wiedział Józef i matka jego.
44 Ṣùgbọ́n wọ́n ṣe bí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ èrò, wọ́n rin ìrìn ọjọ́ kan; wọ́n wá a kiri nínú àwọn ará àti àwọn ojúlùmọ̀ wọn.
Lecz mniemając, że jest w towarzystwie podróżnem, uszli dzień drogi, i szukali go między krewnymi i między znajomymi.
45 Nígbà tí wọn kò sì rí i, wọ́n padà sí Jerusalẹmu, wọ́n ń wá a kiri.
A gdy go nie znaleźli, wrócili się do Jeruzalemu, szukając go,
46 Ó sì ṣe, lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́ta wọ́n rí i nínú tẹmpili ó jókòó ní àárín àwọn olùkọ́ni, ó ń gbọ́ tiwọn, ó sì ń bi wọ́n léèrè.
I stało się po trzech dniach, że go znaleźli siedzącego w kościele w pośrodku doktorów, słuchającego ich i pytającego ich.
47 Ẹnu sì ya gbogbo àwọn tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀ fún òye àti ìdáhùn rẹ̀.
I zdumiewali się wszyscy, którzy go słuchali, nad rozumem i nad odpowiedziami jego.
48 Nígbà tí wọ́n sì rí i, háà ṣe wọ́n, ìyá rẹ̀ sì bi í pé, “Ọmọ, èéṣe tí ìwọ fi ṣe wá bẹ́ẹ̀? Sá wò ó, baba rẹ̀ àti èmi ti ń fi ìbànújẹ́ wá ọ kiri.”
A ujrzawszy go rodzice, zdumieli się. I rzekła do niego matka jego: Synu! przeczżeś nam to uczynił? Oto ojciec twój i ja z boleścią szukaliśmy cię.
49 Ó sì dáhùn wí fún wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń wá mi kiri? Ẹ̀yin kò mọ̀ pé èmi kò lè ṣàìmá wà níbi iṣẹ́ Baba mi?”
I rzekł do nich: Cóż jest, żeście mię szukali? Izaliście nie wiedzieli, iż w tych rzeczach, które są Ojca mego, ja być muszę?
50 Ọ̀rọ̀ tí o sọ kò sì yé wọn.
Lecz oni nie zrozumieli tego słowa, które im mówił.
51 Ó sì bá wọn sọ̀kalẹ̀ lọ sí Nasareti, sì fi ara balẹ̀ fún wọn, ṣùgbọ́n ìyá rẹ̀ pa gbogbo nǹkan wọ̀nyí mọ́ nínú ọkàn rẹ̀.
I zstąpił z nimi, i przyszedł do Nazaretu, a był im poddany. A matka jego zachowywała wszystkie te słowa w sercu swojem.
52 Jesu sì ń pọ̀ ní ọgbọ́n, sì ń dàgbà, ó sì wà ní ojúrere ní ọ̀dọ̀ Ọlọ́run àti ènìyàn.
A Jezus pomnażał się w mądrości, i we wzroście i w łasce u Boga i u ludzi.