< Luke 2 >

1 Ó sì ṣe ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àṣẹ ti ọ̀dọ̀ Kesari Augustu jáde wá pé, kí a kọ orúkọ gbogbo ayé sínú ìwé.
EIA kekahi mea ia mau la, hoolahaia'e la ke kauoha a Kaisara Augusato, e kakauia i ka palapala ko ke aupuni a pau.
2 (Èyí ni ìkọ sínú ìwé èkínní tí a ṣe nígbà tí Kirene fi jẹ baálẹ̀ Siria.)
I ke alii kiaaina ana o Kurenio ma Suria, ka hoomaka ana o keia kakau mua ana.
3 Gbogbo àwọn ènìyàn sì lọ láti kọ orúkọ wọn sínú ìwé, olúkúlùkù sí ìlú ara rẹ̀.
Pau no i ka hele i kakauia'i i ka palapala o kela mea keia mea i kona kulanakauhale iho.
4 Josẹfu pẹ̀lú sì gòkè láti Nasareti ni Galili, sí ìlú Dafidi ní Judea, tí à ń pè ní Bẹtilẹhẹmu; nítorí ti ìran àti ìdílé Dafidi ní í ṣe,
O Iosepa kekahi i pii ae, mai Galilaia ae, mailoko mai o Nazareta ke kulanakauhale a hiki i Iudea, i ko Davida kulanakauhale i kapaia o Betelehema, (no ka mea, no ka hale ia a me ka ohaua a Davida, )
5 láti kọ orúkọ rẹ̀, pẹ̀lú Maria aya rẹ̀ àfẹ́sọ́nà, tí oyún rẹ̀ ti tó bí.
I kakauia'i me Maria ka wahine i hoopalauia nana, e koko ana.
6 Ó sì ṣe, nígbà tí wọ́n wà níbẹ̀, ọjọ́ rẹ̀ pé tí òun yóò bí.
A oiai laua malaila, hiki kona manawa e hanau ai.
7 Ó sì bí àkọ́bí rẹ̀ ọmọkùnrin, ó sì fi ọ̀já wé e, ó sì tẹ́ ẹ sínú ibùjẹ ẹran; nítorí tí ààyè kò sí fún wọn nínú ilé èrò.
Hanau iho la oia i kana makahiapo kane; wahi iho la ia ia i ke kapa keiki, a hoomoe iho la ia ia ma kahi hanai holoholona, no ka mea, aole wahi kaawale no lakou maloko o ka hale hookipa.
8 Àwọn olùṣọ́-àgùntàn ń bẹ tí wọ́n ń gbé ní ìlú náà, wọ́n ń ṣọ́ agbo àgùntàn wọn ní òru ní pápá tí wọ́n ń gbé.
Aia i kela aina he mau kahuhipa e noho ana i ke kula, a e kiai ana i ka lakou mau poe hipa i ka po.
9 Angẹli Olúwa sì yọ sí wọn, ògo Olúwa sì ràn yí wọn ká, ẹ̀rù sì bà wọ́n gidigidi.
Aia hoi! Kau mai la ka anela o ka Haku io lakou la, a hoomalamalama mai la ka nani o ka Haku ia lakou a puni, a makau loa iho la lakou.
10 Angẹli náà sì wí fún wọn pé, “Má bẹ̀rù: sá wò ó, mo mú ìyìnrere ayọ̀ ńlá fún yín wá, tí yóò ṣe ti ènìyàn gbogbo.
A olelo mai la ka anela ia lakou, Mai makau oukou, no ka mea, eia hoi, ke hai aku nei au ia oukou i ka mea maikai, e olioli nui ai e lilo ana no na kanaka a pau.
11 Nítorí a ti bí Olùgbàlà fún yín lónìí ní ìlú Dafidi, tí í ṣe Kristi Olúwa.
No ka mea, i keia la i hanau ai, ma ke kulanakauhale o Davida, he Ola no oukou, oia ka Mesia ka Haku.
12 Èyí ni yóò sì ṣe àmì fún yín; ẹ̀yin yóò rí ọmọ ọwọ́ tí a fi ọ̀já wé, ó dùbúlẹ̀ ní ibùjẹ ẹran.”
Eia hoi ka hoailona no oukou, e loaa auanei ia oukou ke keiki ua wahiia i ke kapa keiki, e moe ana ma kahi hanai holoholona.
13 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ogun ọ̀run sì darapọ̀ mọ́ angẹli náà ní òjijì, wọ́n ń yin Ọlọ́run, wí pé,
A emo ole mai la ka lehulehu o ka puali o ka lani me ua anela la, e hoolea ana i ke Akua, e olelo ana,
14 “Ògo ni fún Ọlọ́run lókè ọ̀run, àti ní ayé àlàáfíà, ìfẹ́ inú rere sí ènìyàn.”
E hoonaniia ke Akua ma na lani kiekie loa, a he malu hoi ma ka honua; he aloha no i kauaka.
15 Ó sì ṣe, nígbà tí àwọn angẹli náà padà kúrò lọ́dọ̀ wọn lọ sí ọ̀run, àwọn olùṣọ́-àgùntàn náà bá ara wọn sọ pé, “Ẹ jẹ́ kí á lọ tààrà sí Bẹtilẹhẹmu, kí á lè rí ohun tí ó ṣẹ̀, tí Olúwa fihàn fún wa.”
Eia hoi kekahi, a hoi aku la na anela i ka lani, mai o lakou aku, olelo iho la ua mau kanaka kiai hipa la kekahi i kekahi, Ea, e haele kakou i Betelehema e'ike aku hoi ia mea a ka Haku i hoike mai nei ia kakou.
16 Wọ́n sì wá lọ́gán, wọ́n sì rí Maria àti Josẹfu, àti ọmọ ọwọ́ náà, ó dùbúlẹ̀ nínú ibùjẹ ẹran.
Haele wikiwiki lakou, a ike iho la ia Maria, a me Iosepa, a me ke keiki, e moe ana ia ma kahi hanai holoholona.
17 Nígbà tí wọ́n sì ti rí i, wọ́n sọ ohun tí a ti wí fún wọn nípa ti ọmọ yìí.
A ike lakou, hoolaha aku la lakou i ka olelo i haiia mai ia lakou no ia keiki.
18 Ẹnu sì ya gbogbo àwọn tí ó gbọ́ sí nǹkan wọ̀nyí tí a ti wí fún wọn láti ọ̀dọ̀ àwọn olùṣọ́-àgùntàn wá.
A o ka poe i lohe a pau, mahalo iho la lakou no na mea i haiia ku ia lakou e ka poe kahuhipa.
19 Ṣùgbọ́n Maria pa gbogbo nǹkan wọ̀nyí mọ́, ó ń rò wọ́n nínú ọkàn rẹ̀.
Kaohi iho la o Maria ia mau mea a pau me ka hoomanao iho iloko o kona naau.
20 Àwọn olùṣọ́-àgùntàn sì padà lọ, wọ́n ń fi ògo fún Ọlọ́run, wọ́n sì yìn ín, nítorí ohun gbogbo tí wọ́n ti gbọ́ àti tí wọ́n ti rí, bí a ti wí i fún wọn.
A hoi mai la na kahuhipa, me ka hoonani a me ka hoolea i ke Akua no ia mau mea a pau a lakou i lohe ai a i ike ai hoi, e like me ka mea i haiia mai ia lakou.
21 Nígbà tí ọjọ́ mẹ́jọ sì pé láti kọ ọmọ náà nílà, wọ́n pe orúkọ rẹ̀ ní Jesu, bí a ti sọ ọ́ tẹ́lẹ̀ láti ọ̀dọ̀ angẹli náà wá kí á tó lóyún rẹ̀.
A hala na la ewalu i okipoepoeia'i ua keiki la, kapaia kona inoa o IESU, o ka ka anela hoi i kapa ai mamua i kona hapaiia iloko o ka opu.
22 Nígbà tí ọjọ́ ìwẹ̀nù Maria sì pé gẹ́gẹ́ bí òfin Mose, Josẹfu àti Maria gbé Jesu wá sí Jerusalẹmu láti fi í fún Olúwa
A pau na la o ko laua hoomaemae ana mamuli o ke kanawai o Mose, lawe ae la lakou ia keiki i Ierusalema e haawi ia ia i ka Haku:
23 (bí a ti kọ ọ́ sínú òfin Olúwa pé, “Gbogbo ọmọ ọkùnrin tí ó ṣe àkọ́bí, òun ni a ó pè ní mímọ́ fún Olúwa”),
(E like me ka mea i kakauia ma ke kanawai o ka Haku, o kela makahiapo kane, keia makahiapo kane, e iia'e he laa no Iehova; )
24 àti láti rú ẹbọ gẹ́gẹ́ bí èyí tí a wí nínú òfin Olúwa: “Àdàbà méjì tàbí ọmọ ẹyẹlé méjì.”
A e haawi hoi i ka mohai i kauohaia mai ma ke kanawai o Iehova, he mau kuhukuku elua, a i ole ia, elua manu nunu opiopio.
25 Sì kíyèsi i, ọkùnrin kan wà ní Jerusalẹmu, orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Simeoni; ọkùnrin náà sì ṣe olóòtítọ́ àti olùfọkànsìn, ó ń retí ìtùnú Israẹli, Ẹ̀mí mímọ́ sì bà lé e.
Aia hoi, ma Ierusalema kekahi kanaka, o Simeona kona inoa; a he kanaka pono ia, he haipule, e kali ana i ka mea nana e kokua i ka Iseraela; aia maluna ona ka Uhane Hemolele.
26 A sì ti fihàn án láti ọ̀dọ̀ Ẹ̀mí Mímọ́ náà wá pé, òun kì yóò rí ikú, kí ó tó rí Kristi Olúwa.
A ua hoike e ia mai ia ia e ka Uhane Hemolele, aole ia e make e, a ike aku ia i ka Mesia a ka Haku.
27 Ó sì ti ipa Ẹ̀mí wá sínú tẹmpili. Nígbà tí àwọn òbí rẹ̀ sì gbé Jesu wá, láti ṣe fún un bí ìṣe òfin.
A hele ae la hoi ia mamuli o ka Uhane iloko o ka luakini; a lawe ae la na makua i ke keiki ia Iesu iloko, e hana aku ai nona mamuli o ka oihana o ke kanawai;
28 Nígbà náà ni Simeoni gbé e ní apá rẹ̀, ó fi ìbùkún fún Ọlọ́run, ó ní:
Alaila lawe oia ia ia ma kona mau lima, a hoomaikai aku la i ke Akua, i aku la hoi,
29 “Olúwa Olódùmarè, nígbà yìí ni ó tó jọ̀wọ́ ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ lọ́wọ́ lọ, ní àlàáfíà, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Ano, e ka Haku, ke kuu nei oe i kau kauwa nei me ka pomaikai e like me kau olelo.
30 Nítorí tí ojú mi ti rí ìgbàlà rẹ ná,
No ka mea, ua ike iho nei ko'u mau maka i kau Hoola,
31 tí ìwọ ti pèsè sílẹ̀ níwájú ènìyàn gbogbo;
Ka mea au i hoomakaukau ai imua o ke alo o na kanaka a pau;
32 ìmọ́lẹ̀ láti mọ́ sí àwọn aláìkọlà, àti ògo Israẹli ènìyàn rẹ̀.”
He malamalama e hoomalamalama ai i na lahuikanaka, a he nani no kou poe kanaka ka Iseraela.
33 Ẹnu sì ya Josẹfu àti ìyá rẹ̀ sí nǹkan tí a ń sọ sí i wọ̀nyí.
Mahalo iho la o Iosepa a me kona makuwahine ia mau mea i oleloia mai ai nona.
34 Simeoni sì súre fún wọn, ó sì wí fún Maria ìyá rẹ̀ pé, “Kíyèsi i, a gbé ọmọ yìí kalẹ̀ fún ìṣubú àti ìdìde ọ̀pọ̀ ènìyàn ní Israẹli; àti fún àmì tí a ń sọ̀rọ̀-òdì sí;
A hoomaikai mai la o Simeona ia laua, i mai la hoi oia ia Maria i kona makuwahine, Eia hoi, ua hoonohonohoia mai oia nei i mea e haule ai, a e ala hou ai na mea he nui iwaena o ka Iseraela, a i hoailona hoi o hoinoia'i;
35 (idà yóò sì gún ìwọ náà ní ọkàn pẹ̀lú) kí á lè fi ìrònú ọ̀pọ̀ ọkàn hàn.”
(A e houia no hoi kou uhane e ka pahikaua; ) i hoikeia'i na manao o na naau he lehulehu.
36 Ẹnìkan sì ń bẹ, Anna wòlíì, ọmọbìnrin Penueli, nínú ẹ̀yà Aṣeri: ọjọ́ ogbó rẹ̀ pọ̀, ó ti bá ọkọ gbé ní ọdún méje láti ìgbà wúńdíá rẹ̀ wá;
Malaila hoi kekahi kaula wahine, o Ana, ke kaikamahine a Panuela, na ka ohana a Asera; he kahiko no ia, a ehiku makahiki ona i noho pu ai me ke kane, mai kona wa puupaa mai.
37 Ó sì ṣe opó títí ó fi di ẹni ọdún mẹ́rìnlélọ́gọ́rin, ẹni tí kò kúrò ní tẹmpili, ṣùgbọ́n ó ń fi àwẹ̀ àti àdúrà sin Ọlọ́run lọ́sàn án àti lóru.
A he wahine kanemake ia, he kanawalukumamaha makahiki ona, aole hoi ia i haalele i ka luakini, aka, ua malama mau oia i ke Akua me ka hoopololi a me ka pule, i ka po a me ke ao.
38 Ó sì wólẹ̀ ní àkókò náà, ó sì dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run pẹ̀lú, ó sì sọ̀rọ̀ rẹ̀ fún gbogbo àwọn tí ó ń retí ìdáǹdè Jerusalẹmu.
A komo mai la oia ia manawa, hoomaikai aku la i ka Haku, a olelo mai la ia no ua keiki la i ka poe a pau e kali ana i ke ola ma Ierusalema.
39 Nígbà tí wọ́n sì ti ṣe nǹkan gbogbo tán gẹ́gẹ́ bí òfin Olúwa, wọ́n padà lọ sí Galili, sí Nasareti ìlú wọn.
A pau ae la i ka hanaia na mea i kauohaia ma ke kanawai o ka Haku, hoi ae la lakou i Galilaia, i ko lakou kulanakauhale i Nazareta.
40 Ọmọ náà sì ń dàgbà, ó sì ń lágbára, ó sì kún fún ọgbọ́n: oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run sì ń bẹ lára rẹ̀.
A nui ae la ua keiki la, a ikaika ae la hoi kona manao, a piha i ka naauao, a maluna ona ke aloha o ke Akua.
41 Àwọn òbí rẹ̀ a sì máa lọ sí Jerusalẹmu ní ọdọọdún sí àjọ ìrékọjá.
Hele na makua ona i Ierusalema i kela makahiki i keia makahiki i ka ahaaina moliaola.
42 Nígbà tí ó sì di ọmọ ọdún méjìlá, wọ́n gòkè lọ sí Jerusalẹmu gẹ́gẹ́ bí ìṣe àjọ náà.
A i ka umikumamalua o kona mau makahiki, pii ae la lakou i Ierusalema mamuli o ka oihana o ka ahaaina.
43 Nígbà tí ọjọ́ wọn sì pé bí wọ́n ti ń padà bọ̀, ọmọ náà, Jesu dúró lẹ́yìn ní Jerusalẹmu; Josẹfu àti ìyá rẹ̀ kò mọ̀.
A pau ia mau la, hoi ae la laua, noho iho la ke keiki o Iesu, ma Ierusalema, aole hoi i ike o Iosepa a me kona makuwahine.
44 Ṣùgbọ́n wọ́n ṣe bí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ èrò, wọ́n rin ìrìn ọjọ́ kan; wọ́n wá a kiri nínú àwọn ará àti àwọn ojúlùmọ̀ wọn.
Manao no laua, aia no ia maloko o ka huakai, hele no laua i ko kekahi la hele ana; a imi iho la laua ia ia mawaena o na hoahanau a me ua hoalauna.
45 Nígbà tí wọn kò sì rí i, wọ́n padà sí Jerusalẹmu, wọ́n ń wá a kiri.
Aole oia i loaa ia laua, hoi hou ae la laua i Ierusalema, e imi ana ia ia.
46 Ó sì ṣe, lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́ta wọ́n rí i nínú tẹmpili ó jókòó ní àárín àwọn olùkọ́ni, ó ń gbọ́ tiwọn, ó sì ń bi wọ́n léèrè.
Eia kekahi, a hala na la ekolu, ike aku la laua ia ia iloko o ka luakini e noho ana mawaena o ka poe kumu, e hoolohe ana ia lakou, a e ninau ana hoi ia lakou.
47 Ẹnu sì ya gbogbo àwọn tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀ fún òye àti ìdáhùn rẹ̀.
A o ka poe a pau i lohe ia ia, mahalo iho la i kona naauao a me kana olelo ana.
48 Nígbà tí wọ́n sì rí i, háà ṣe wọ́n, ìyá rẹ̀ sì bi í pé, “Ọmọ, èéṣe tí ìwọ fi ṣe wá bẹ́ẹ̀? Sá wò ó, baba rẹ̀ àti èmi ti ń fi ìbànújẹ́ wá ọ kiri.”
A ike laua ia ia, pihoihoi iho la; a i aku la kona makuwahine ia ia, E ka'u keiki, no ke aha la oe i hana mai ai pela ia maua? Ea, ua imi ae nei maua me kou makuakane ia oe, me ke kaumaha.
49 Ó sì dáhùn wí fún wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń wá mi kiri? Ẹ̀yin kò mọ̀ pé èmi kò lè ṣàìmá wà níbi iṣẹ́ Baba mi?”
I mai la kela ia laua, No ke aha la olua i imi mai nei ia'u? Aole anei olua i manao he pono nu'u e lilo ma ka ko'u Makua?
50 Ọ̀rọ̀ tí o sọ kò sì yé wọn.
Aole laua i ike i ke ano o kana mea i olelo mai ai ia laua.
51 Ó sì bá wọn sọ̀kalẹ̀ lọ sí Nasareti, sì fi ara balẹ̀ fún wọn, ṣùgbọ́n ìyá rẹ̀ pa gbogbo nǹkan wọ̀nyí mọ́ nínú ọkàn rẹ̀.
A iho ae la ia me laua a hiki i Nazareta, a noho ia malalo iho o laua: a malama iho la kona makuwahine ia mau mea a pau ma kona naau.
52 Jesu sì ń pọ̀ ní ọgbọ́n, sì ń dàgbà, ó sì wà ní ojúrere ní ọ̀dọ̀ Ọlọ́run àti ènìyàn.
A nui ae la ka naauao, a me ke kino o Iesu, a me ke alohaia e ke Akua a me na kanaka.

< Luke 2 >