< Luke 2 >
1 Ó sì ṣe ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àṣẹ ti ọ̀dọ̀ Kesari Augustu jáde wá pé, kí a kọ orúkọ gbogbo ayé sínú ìwé.
ⲁ̅ⲁⲥϣⲱⲡⲓ ϧⲉⲛ ⲛⲓ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲁϥ⳿ⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛϫⲉ ⲩϩⲱⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ ⳿ⲡⲟⲩⲣⲟ ⲁⲩⲅⲟⲩⲥⲧⲟⲥ ϫⲉ ⳿ⲛⲧⲉ ϯⲟⲓⲕⲟⲓⲙⲉⲛⲏ ⲧⲏⲣⲥ ϯ ⲣⲉⲛⲥ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉ⳿ⲥϧⲁⲓ.
2 (Èyí ni ìkọ sínú ìwé èkínní tí a ṣe nígbà tí Kirene fi jẹ baálẹ̀ Siria.)
ⲃ̅ⲑⲁⲓ ⲧⲉ ϯ⳿ⲁⲡⲟⲅⲣⲁⲫⲏ ⳿ⲛϩⲟⲩⲓϯ ⲧⲁⲥϣⲱⲡⲓ ⲉϥⲟⲓ ⳿ⲛϩⲏⲅⲉⲙⲱⲛ ⳿ⲉϯⲥⲩⲣⲓⲁ ⳿ⲛϫⲉ ⲕⲩⲣⲓⲛⲛⲓⲟⲥ.
3 Gbogbo àwọn ènìyàn sì lọ láti kọ orúkọ wọn sínú ìwé, olúkúlùkù sí ìlú ara rẹ̀.
ⲅ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁⲩⲛⲁ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⳿ⲉ⳿ⲥϧⲉ ⲡⲟⲩⲣⲁⲛ ⲡⲓⲟⲩⲁⲓ ⲡⲓⲟⲩⲁⲓ ⳿ⲛⲥⲁ ⲧⲉϥⲃⲁⲕⲓ.
4 Josẹfu pẹ̀lú sì gòkè láti Nasareti ni Galili, sí ìlú Dafidi ní Judea, tí à ń pè ní Bẹtilẹhẹmu; nítorí ti ìran àti ìdílé Dafidi ní í ṣe,
ⲇ̅ϥ⳿ⲓ ⲇⲉ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲛϫⲉ ⳿ⲡⲕⲉⲓⲱⲥⲏⲫ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ϯⲅⲁⲗⲓⲗⲉ⳿ⲁ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲃⲁⲕⲓ ϫⲉ ⲛⲁⲍⲁⲣⲉⲑ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉⲟⲩⲃⲁⲕⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲇⲁⲩⲓⲇ ⲉⲩⲙⲟⲩϯ ⳿ⲉⲣⲟⲥ ϫⲉ ⲏⲑⲗⲉⲉⲙ ⲉⲑⲃⲉϫⲉ ⲟⲩ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⳿ⲡⲏⲓ ⲛⲉⲙ ⳿ⲑⲙⲉⲧⲓⲱⲧ ⳿ⲛⲇⲁⲩⲓⲇ ⲡⲉ.
5 láti kọ orúkọ rẹ̀, pẹ̀lú Maria aya rẹ̀ àfẹ́sọ́nà, tí oyún rẹ̀ ti tó bí.
ⲉ̅⳿ⲉ⳿ⲥϧⲉ ⲡⲉϥⲣⲁⲛ ⲛⲉⲙ ⲙⲁⲣⲓⲁⲙ ⲑⲏ ⲉⲧⲁⲩⲱⲡ ⳿ⲛⲥⲱⲥ ⲛⲁϥ ⲉⲥ⳿ⲙⲃⲟⲕⲓ.
6 Ó sì ṣe, nígbà tí wọ́n wà níbẹ̀, ọjọ́ rẹ̀ pé tí òun yóò bí.
ⲋ̅ⲁⲥϣⲱⲡⲓ ⲇⲉ ⲉⲩⲭⲏ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲁⲩⲙⲟϩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲉⲥ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⲉⲑⲣⲉⲥⲙⲓⲥⲓ.
7 Ó sì bí àkọ́bí rẹ̀ ọmọkùnrin, ó sì fi ọ̀já wé e, ó sì tẹ́ ẹ sínú ibùjẹ ẹran; nítorí tí ààyè kò sí fún wọn nínú ilé èrò.
ⲍ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁⲥⲙⲓⲥⲓ ⳿ⲙⲡⲉⲥϣⲏⲣⲓ ⲡⲓϣⲟⲣⲡ ⳿ⲙⲙⲓⲥⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲥⲕⲟⲩⲗⲱⲗϥ ⲁⲥⲭⲁϥ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲟⲩⲟⲛϩϥ ϫⲉ ⲟⲩⲏⲓ ⲛⲉ ⳿ⲙⲙⲟⲛⲧⲟⲩ ⲙⲁ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲡⲉ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲙⲁ⳿ⲛⲟⲩⲟϩ.
8 Àwọn olùṣọ́-àgùntàn ń bẹ tí wọ́n ń gbé ní ìlú náà, wọ́n ń ṣọ́ agbo àgùntàn wọn ní òru ní pápá tí wọ́n ń gbé.
ⲏ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲉ ⲟⲩⲟⲛ ϩⲁⲛⲙⲁⲛ⳿ⲉⲥⲱⲟⲩ ⲩⲙⲟⲛⲓ ϧⲉⲛ ϯⲭⲱⲣⲁ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲁⲩ ϧⲉⲛ ⳿ⲧⲕⲟⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲩⲣⲱⲓⲥ ϧⲉⲛ ⲛⲓⲣⲱⲓⲥ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓ⳿ⲉϫⲱⲣϩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲡⲟⲩⲟϩⲓ ⳿ⲛ⳿ⲉⲥⲱⲟⲩ.
9 Angẹli Olúwa sì yọ sí wọn, ògo Olúwa sì ràn yí wọn ká, ẹ̀rù sì bà wọ́n gidigidi.
ⲑ̅ⲟⲩⲟϩ ⲓⲥ ⲩⲁⲅⲅⲉⲗⲟⲥ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲡ⳪ ⲁϥ⳿ⲟϩⲓ ⳿ⲉⲣⲁⲧϥ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉϫⲱⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲟⲩⲱⲟⲩ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲡ⳪ ⲁϥⲉⲣⲟⲩⲱⲓⲛⲓ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩⲉⲣϩⲟϯ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲛⲓϣϯ ⳿ⲛϩⲟϯ ⲉⲙⲁϣⲱ.
10 Angẹli náà sì wí fún wọn pé, “Má bẹ̀rù: sá wò ó, mo mú ìyìnrere ayọ̀ ńlá fún yín wá, tí yóò ṣe ti ènìyàn gbogbo.
ⲓ̅⳿ⲛⲑⲟϥ ⲇⲉ ⲉϫⲁϥ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ϩⲏⲡⲡⲉ ⲉⲣⲉⲧⲉⲛⲛⲁϣⲉ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉϯⲃⲁⲕⲓ ⳿ϥⲛⲁ⳿ⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ ⲟⲩⲣⲱⲙⲓ ⲉϥϥⲁⲓ ⳿ⲛⲟⲩϣⲟϣⲟⲩ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⲙⲟϣⲓ ⲛⲥⲱϥ ⳿ⲉⲡⲓⲏⲓ ⲉⲧⲉ⳿ϥⲛⲁϣⲉ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉⲣⲟϥ.
11 Nítorí a ti bí Olùgbàlà fún yín lónìí ní ìlú Dafidi, tí í ṣe Kristi Olúwa.
ⲓ̅ⲁ̅ϫⲉ ⲁⲩⲙⲓⲥⲓ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲙⲫⲟⲟⲩ ⳿ⲛⲟⲩⲥⲱⲧⲏ ⲣ ⲉⲧⲉ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ Ⲡ⳪ ⲡⲉ ϧⲉⲛ ⳿ⲑⲃⲁⲕⲓ ⳿ⲛⲇⲁⲩⲓⲇ.
12 Èyí ni yóò sì ṣe àmì fún yín; ẹ̀yin yóò rí ọmọ ọwọ́ tí a fi ọ̀já wé, ó dùbúlẹ̀ ní ibùjẹ ẹran.”
ⲓ̅ⲃ̅ⲟⲩⲟϩ ⲫⲁⲓ ⲡⲉ ⲓⲙⲏⲓⲛⲓ ⲱⲧⲉⲛ ⲉⲣⲉⲧⲉⲛ⳿ⲉϫⲓⲙⲓ ⳿ⲛⲟⲩ⳿ⲁⲗⲟⲩ ⲉϥⲕⲟⲩⲗⲱⲗ ⲟⲩⲟϩ ⲉϥⲭⲏ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲟⲩⲟⲛϩϥ.
13 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ogun ọ̀run sì darapọ̀ mọ́ angẹli náà ní òjijì, wọ́n ń yin Ọlọ́run, wí pé,
ⲓ̅ⲅ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁⲥϣⲱⲡⲓ ⳿ⲛⲟⲩϩⲟϯ ϧⲉⲛ ⲟⲩϩⲟϯ ⳿ⲛϫⲉ ⲟⲩⲙⲏϣ ⲙⲙⲉⲧⲙⲁⲧⲟⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⳿ⲧⲫⲉ ⲛⲉⲙ ⲡⲓⲁⲅⲅⲉⲗⲟⲥ ⲉⲩϩⲱⲥ ⳿ⲉⲫϯ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲩϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ.
14 “Ògo ni fún Ọlọ́run lókè ọ̀run, àti ní ayé àlàáfíà, ìfẹ́ inú rere sí ènìyàn.”
ⲓ̅ⲇ̅ϫⲉ ⲟⲩⲱⲟⲩ ϧⲉⲛ ⲛⲏⲉⲧϭⲟⲥⲓ ⳿ⲙⲫϯ ⲛⲉⲙ ⲟⲩϩⲓⲣⲏⲛⲏ ⲓϫⲉⲛ ⲡⲓⲕⲁϩⲓ ⲛⲉⲙ ⲟⲩ ϯⲙⲁϯ ϧⲉⲛ ⲛⲓⲣⲱⲙⲓ.
15 Ó sì ṣe, nígbà tí àwọn angẹli náà padà kúrò lọ́dọ̀ wọn lọ sí ọ̀run, àwọn olùṣọ́-àgùntàn náà bá ara wọn sọ pé, “Ẹ jẹ́ kí á lọ tààrà sí Bẹtilẹhẹmu, kí á lè rí ohun tí ó ṣẹ̀, tí Olúwa fihàn fún wa.”
ⲓ̅ⲉ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁⲥϣⲱⲡⲓ ⲉⲧⲁⲩϣⲉ ⲛⲱⲟⲩ ⳿ⲉ⳿ⲧⲫⲉ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲁⲣⲱⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲓⲁⲅⲅⲉⲗⲟⲥ ⲁⲩⲥⲁϫⲓ ⳿ⲛϫⲉ ⲓⲙⲁⲛ⳿ⲉⲥⲱⲟⲩ ⲛⲉⲙ ⲛⲟⲩ⳿ⲉⲣⲏⲟⲩ ⲉⲩϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲙⲁⲣⲟⲛ ϣⲁ ⲃⲏⲑⲗⲉⲉⲙ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲉⲛⲛⲁⲩ ⲉⲑⲃⲉ ⲡⲁⲓⲥⲁϫⲓ ⲉⲧⲁϥϣⲱⲡⲓ ⲫⲁⲓ ⲉⲧⲁ Ⲡ⳪ ⲧⲁⲙⲟⲛ ⲉⲣⲟϥ.
16 Wọ́n sì wá lọ́gán, wọ́n sì rí Maria àti Josẹfu, àti ọmọ ọwọ́ náà, ó dùbúlẹ̀ nínú ibùjẹ ẹran.
ⲓ̅ⲋ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩ⳿ⲓ ⲉⲩⲓⲏⲥ ⲁⲩϫⲓⲙⲓ ⳿ⲙⲙⲁⲣⲓ⳿ⲁ ⲛⲉⲙ ⲓⲱⲥⲏⲫ ⲛⲉⲙ ⲡⲓ⳿ⲁⲗⲟⲩ ⲉϥⲭⲏ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲟⲩⲟⲛϩϥ.
17 Nígbà tí wọ́n sì ti rí i, wọ́n sọ ohun tí a ti wí fún wọn nípa ti ọmọ yìí.
ⲓ̅ⲍ̅ⲉⲧⲁⲩⲛⲁⲩ ⲇⲉ ⲁⲩ⳿ⲉⲙⲓ ⲉⲑⲃⲉ ⲓⲥⲁϫⲓ ⲉⲧⲁⲩⲥⲁϫⲓ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲛⲉⲙⲱⲟⲩ ⲉⲑⲃⲉ ⲡⲓ⳿ⲁⲗⲟⲩ.
18 Ẹnu sì ya gbogbo àwọn tí ó gbọ́ sí nǹkan wọ̀nyí tí a ti wí fún wọn láti ọ̀dọ̀ àwọn olùṣọ́-àgùntàn wá.
ⲓ̅ⲏ̅ⲟⲩⲟϩ ⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲉⲧⲁⲩⲥⲱⲧⲉⲙ ⲁⲩⲉⲣ⳿ϣⲫⲏⲣⲓ ⲉϫⲉⲛ ⲛⲏⲉⲧⲁⲩⲥⲁϫⲓ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⲛⲉⲙⲱⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲓⲙⲁⲛ⳿ⲉⲥⲱⲟⲩ.
19 Ṣùgbọ́n Maria pa gbogbo nǹkan wọ̀nyí mọ́, ó ń rò wọ́n nínú ọkàn rẹ̀.
ⲓ̅ⲑ̅ⲙⲁⲣⲓ⳿ⲁ ⲇⲉ ⳿ⲛⲑⲟⲥ ⲛⲁⲥⲁⲣⲉϩ ⳿ⲉⲛⲁⲓⲥⲁϫⲓ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⲉⲥⲥⲟϭⲛⲓ ϧⲉⲛ ⲡⲉⲥϩⲏⲧ.
20 Àwọn olùṣọ́-àgùntàn sì padà lọ, wọ́n ń fi ògo fún Ọlọ́run, wọ́n sì yìn ín, nítorí ohun gbogbo tí wọ́n ti gbọ́ àti tí wọ́n ti rí, bí a ti wí i fún wọn.
ⲕ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩⲧⲁⲥⲑⲟ ⳿ⲛϫⲉ ⲓⲙⲁⲛ⳿ⲉⲥⲱⲟⲩ ⲉⲩϯⲱⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲩϩⲱⲥ ⳿ⲉⲫϯ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲉⲧⲁⲩⲥⲟⲑⲙⲟⲩ ⲛⲉⲙ ⲛⲏⲉⲧⲁⲩⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ ⲕⲁⲧⲁ⳿ⲫⲣⲏϯ ⲉⲧⲁⲩⲥⲁϫⲓ ⲛⲉⲙⲱⲟⲩ.
21 Nígbà tí ọjọ́ mẹ́jọ sì pé láti kọ ọmọ náà nílà, wọ́n pe orúkọ rẹ̀ ní Jesu, bí a ti sọ ọ́ tẹ́lẹ̀ láti ọ̀dọ̀ angẹli náà wá kí á tó lóyún rẹ̀.
ⲕ̅ⲁ̅ⲟⲩⲟϩ ⲉⲧⲁⲩⲙⲟϩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛϫⲉ ⲏ̅ ⳿ⲛ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ϫⲉ ⳿ⲛⲧⲟⲩⲥⲟⲩⲃⲏⲧϥ ⲁⲩⲙⲟⲩϯ ⳿ⲉⲡⲉϥⲣⲁⲛ ϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲫⲏⲉⲧⲁϥⲙⲟⲩϯ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲓⲁⲅⲅⲉⲗⲟⲥ ⲓⲥϫⲉⲛ ⳿ⲙⲡⲁⲧⲟⲩⲉⲣⲃⲟⲕⲓ ⳿ⲙⲙⲟϥ ϧⲉⲛ ⳿ⲑⲛⲉϫⲓ.
22 Nígbà tí ọjọ́ ìwẹ̀nù Maria sì pé gẹ́gẹ́ bí òfin Mose, Josẹfu àti Maria gbé Jesu wá sí Jerusalẹmu láti fi í fún Olúwa
ⲕ̅ⲃ̅ⲟⲩⲟϩ ⲉⲧⲁ ⲛⲓ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⲙⲟϩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓⲧⲟⲩⲃⲟ ⲕⲁⲧⲁ ⲡⲓⲛⲟⲙⲟⲥ ⳿ⲛⲧⲉ ⲱ⳿ⲩⲥⲏⲥ ⲁⲩ⳿ⲉⲛϥ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉ⳿ⲓⲗ̅ⲏ̅ⲙ̅ ⳿ⲉⲧⲁϩⲟϥ ⳿ⲉⲣⲁⲧϥ ⳿ⲙⲠ⳪.
23 (bí a ti kọ ọ́ sínú òfin Olúwa pé, “Gbogbo ọmọ ọkùnrin tí ó ṣe àkọ́bí, òun ni a ó pè ní mímọ́ fún Olúwa”),
ⲕ̅ⲅ̅ⲕⲁⲧⲁ⳿ⲫⲣⲏϯ ⲉⲧ⳿ⲥϧⲏⲟⲩⲧ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲛⲟⲙⲟⲥ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲡ⳪ ϫⲉ ϩⲱⲟⲩⲧ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲑⲛⲁⲟⲩⲱⲛ ⳿ⲉⲧⲟϯ ⳿ⲛⲧⲉ ⲧⲉϥⲙⲁⲩ ⲉⲩ⳿ⲉⲙⲟⲩϯ ⳿ⲉⲣⲟϥ ϫⲉ ⲡⲉⲑⲟⲩⲁⲃ ⳿ⲙⲠ⳪.
24 àti láti rú ẹbọ gẹ́gẹ́ bí èyí tí a wí nínú òfin Olúwa: “Àdàbà méjì tàbí ọmọ ẹyẹlé méjì.”
ⲕ̅ⲇ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉϯ ⳿ⲛⲟⲩϣⲟⲩϣⲱⲟⲩϣⲓ ⲕⲁⲧⲁ⳿ⲫⲣⲏϯ ⲉⲧⲁⲩϫⲟⲥ ϩⲓ ⲛⲟⲙⲟⲥ ⳿ⲙⲠ⳪ ϫⲉ ⲟⲩϣⲱϣ ⳿ⲛϭⲣⲟⲙ⳿ⲡϣⲁⲗ ⲓⲉ ⲙⲁⲥ ⲃ̅ ⳿ⲛϭ ⲣⲟⲙⲡⲓ.
25 Sì kíyèsi i, ọkùnrin kan wà ní Jerusalẹmu, orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Simeoni; ọkùnrin náà sì ṣe olóòtítọ́ àti olùfọkànsìn, ó ń retí ìtùnú Israẹli, Ẹ̀mí mímọ́ sì bà lé e.
ⲕ̅ⲉ̅ⲟⲩⲟϩ ⲓⲥ ϩⲏⲡⲡⲉ ⲛⲉ ⲟⲩⲣⲱⲙⲓ ϧⲉⲛ ⳿ⲓⲗ̅ⲏ̅ⲙ̅ ⳿ⲉⲡⲉϥⲣⲁⲛ ⲡⲉ ⲥⲓⲙⲱⲛ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲓⲣⲱⲙⲓ ⲛⲉ ⲟⲩⲇⲓⲕⲉⲟⲥ ⲡⲉ ⳿ⲛⲣⲉϥⲉⲣϩⲟϯ ⲉϥϫⲟⲩϣⲧ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲁ⳿ⲧϩⲏ ⳿ⲙ⳿ⲡϯⲛⲟⲙϯ ⳿ⲙⲡⲓⲥ̅ⲗ̅ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲉ ⲟⲩⲟⲛ ⲡ͞ⲛⲁ̅ ⲉϥⲟⲩⲁⲃ ⲭⲏ ϩⲓϫⲱϥ.
26 A sì ti fihàn án láti ọ̀dọ̀ Ẹ̀mí Mímọ́ náà wá pé, òun kì yóò rí ikú, kí ó tó rí Kristi Olúwa.
ⲕ̅ⲋ̅ⲩⲟϩ ⲛⲉ ⲁⲩⲧⲁⲙⲟϥ ⲡⲉ ϧⲉⲛ ⲟⲩ ⳿ⲭⲣⲏⲙⲁⲧⲓⲥⲙⲟⲥ ⳿ⲛⲧⲟⲧϥ ⳿ⲙⲡⲓⲡ͞ⲛⲁ̅ ⲉⲑⲟⲩⲁⲃ ⳿ⲉ⳿ϣⲧⲉⲙⲉⲑⲣⲉϥⲛⲁⲩ ⳿ⲉ⳿ⲫⲙⲟⲩ ⳿ⲙⲡⲁⲧⲉϥⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲠⲭ̅ⲥ̅ Ⲡ⳪.
27 Ó sì ti ipa Ẹ̀mí wá sínú tẹmpili. Nígbà tí àwọn òbí rẹ̀ sì gbé Jesu wá, láti ṣe fún un bí ìṣe òfin.
ⲕ̅ⲍ̅ⲩⲟϩ ⲁϥ⳿ⲓ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲡ͞ⲛⲁ̅ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉⲡⲓⲉⲣⲫⲉⲓ ⲟⲩⲟϩ ϧⲉⲛ ⳿ⲡϫⲓⲛⲧⲟⲩⲉⲛ ⲡⲓ⳿ⲁⲗⲟⲩ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲉϥⲓⲟϯ ⳿ⲉ⳿ⲓⲣⲓ ⳿ⲉϫⲱϥ ⲕⲁⲧⲁ ⲡⲉⲧ⳿ⲥϣⲉ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓⲛⲟⲙⲟⲥ.
28 Nígbà náà ni Simeoni gbé e ní apá rẹ̀, ó fi ìbùkún fún Ọlọ́run, ó ní:
ⲕ̅ⲏ̅ⲁϥⲟⲗϥ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲛⲉϥϭⲛⲁⲩϩ ⳿ⲛϫⲉ ⲥⲓⲙⲱⲛ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥ⳿ⲥⲙⲟⲩ ⳿ⲉⲫϯ ⲉϥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ.
29 “Olúwa Olódùmarè, nígbà yìí ni ó tó jọ̀wọ́ ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ lọ́wọ́ lọ, ní àlàáfíà, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
ⲕ̅ⲑ̅ϯⲛⲟⲩ ⲡⲁⲛⲏⲃ ⳿ⲭⲛⲁⲭⲁ ⲡⲉⲕⲃⲱⲕ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲩϩⲓⲣⲏⲛⲏ ⲕⲁⲧⲁ ⲡⲉⲕⲥⲁϫⲓ.
30 Nítorí tí ojú mi ti rí ìgbàlà rẹ ná,
ⲗ̅ϫⲉ ⲁⲩⲛⲁⲩ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲁⲃⲁⲗ ⳿ⲉⲡⲉⲕⲛⲟϩⲉⲙ.
31 tí ìwọ ti pèsè sílẹ̀ níwájú ènìyàn gbogbo;
ⲗ̅ⲁ̅ⲫⲏⲉⲧⲁⲕⲥⲉⲃⲧⲱⲧϥ ⳿ⲙⲡⲉ⳿ⲙⲑⲟ ⳿ⲛⲛⲓⲗⲁⲟⲥ ⲧⲏⲣⲟⲩ.
32 ìmọ́lẹ̀ láti mọ́ sí àwọn aláìkọlà, àti ògo Israẹli ènìyàn rẹ̀.”
ⲗ̅ⲃ̅ⲟⲩⲟⲩⲱⲓⲛⲓ ⲉⲩϭⲱⲣⲡ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛⲧⲉ ϩⲁⲛⲉⲑⲛⲟⲥ ⲛⲉⲙ ⲟⲩⲱⲟⲩ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲉⲕⲗⲁⲟⲥ ⲡⲓⲥ̅ⲗ̅.
33 Ẹnu sì ya Josẹfu àti ìyá rẹ̀ sí nǹkan tí a ń sọ sí i wọ̀nyí.
ⲗ̅ⲅ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩⲉⲣ⳿ϣⲫⲏⲣⲓ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲉϥⲓⲱⲧ ⲛⲉⲙ ⲧⲉϥⲙⲁⲩ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲛⲏⲉⲧⲟⲩϫⲱ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⲉⲑⲃⲏⲧϥ.
34 Simeoni sì súre fún wọn, ó sì wí fún Maria ìyá rẹ̀ pé, “Kíyèsi i, a gbé ọmọ yìí kalẹ̀ fún ìṣubú àti ìdìde ọ̀pọ̀ ènìyàn ní Israẹli; àti fún àmì tí a ń sọ̀rọ̀-òdì sí;
ⲗ̅ⲇ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁϥ⳿ⲥⲙⲟⲩ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ ⲥⲓⲙⲱⲛ ⲟⲩⲟϩ ⲡⲉϫⲁϥ ⳿ⲙⲙⲁⲣⲓ⳿ⲁ ⳿ⲑⲙⲁⲩ ⳿ⲙⲡⲓ⳿ⲁⲗⲟⲩ ϫⲉ ⲓⲥ ⲫⲁⲓ ⳿ϥⲭⲏ ⳿ⲉⲟⲩϩⲉⲓ ⲛⲉⲙ ⲟⲩⲧⲱⲛϥ ⳿ⲛⲧⲉ ϩⲁⲛⲙⲏϣ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲥ̅ⲗ̅ ⲛⲉⲙ ⲟⲩⲙⲏⲓⲛⲓ ⲉⲩϯ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲁϥ.
35 (idà yóò sì gún ìwọ náà ní ọkàn pẹ̀lú) kí á lè fi ìrònú ọ̀pọ̀ ọkàn hàn.”
ⲗ̅ⲉ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲑⲟ ϩⲱⲓ ⲉⲣⲉ ⲟⲩⲥⲏϥⲓ ⲥⲓⲛⲓ ⳿ⲛⲧⲉⲯⲩⲭⲏ ϩⲟⲡⲱⲥ ⳿ⲛⲧⲟⲩϭⲱⲣⲡ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ϩⲁⲛⲙⲏϣ ⳿ⲛϩⲏⲧ ⳿ⲛϫⲉ ϩⲁⲛⲙⲉⲩⲓ.
36 Ẹnìkan sì ń bẹ, Anna wòlíì, ọmọbìnrin Penueli, nínú ẹ̀yà Aṣeri: ọjọ́ ogbó rẹ̀ pọ̀, ó ti bá ọkọ gbé ní ọdún méje láti ìgbà wúńdíá rẹ̀ wá;
ⲗ̅ⲋ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁⲣⲉ ⲁⲛⲛⲁ ϯ⳿ⲡⲣⲟⲫⲏⲧⲏⲥ ⳿ⲧϣⲉⲣⲓ ⳿ⲛⲫⲁⲛⲟⲩⲏⲗ ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⳿ⲧⲫⲩⲗⲏ ⳿ⲛⲁⲥⲥⲏ ⲣ ⲑⲁⲓ ⲛⲁⲥⲁⲓⲁⲓ ⳿ⲛⲟⲩⲙⲏϣ ⳿ⲛ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⲛⲁⲥⲱⲛϧ ⲛⲉⲙ ϩⲁⲓ ⳿ⲛⲍ̅ ⳿ⲛⲣⲟⲙⲡⲓ ⲓⲥϫⲉⲛ ⲧⲉⲥⲙⲉⲧⲡⲁⲣⲑⲉⲛⲟⲥ.
37 Ó sì ṣe opó títí ó fi di ẹni ọdún mẹ́rìnlélọ́gọ́rin, ẹni tí kò kúrò ní tẹmpili, ṣùgbọ́n ó ń fi àwẹ̀ àti àdúrà sin Ọlọ́run lọ́sàn án àti lóru.
ⲗ̅ⲍ̅ⲟⲩⲟϩ ⲑⲁⲓ ⲉ ⲁⲥⲉⲣⲭⲏⲣⲁ ϣⲁ ⲡ̅ⲇ̅ ⳿ⲛⲣⲟⲙⲡⲓ ⲑⲏ ⲉⲛⲁⲥⲥⲓⲛⲓ ⳿ⲙⲡⲓⲉⲣⲫⲉⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲁⲛ ⲡⲉ ϧⲉⲛ ϩⲁⲛⲛⲏⲥⲧⲓ⳿ⲁ ⲛⲉⲙ ϩⲁⲛⲧⲱⲃϩ ⲉⲥϣⲉⲙϣⲓ ⳿ⲛϫⲱⲣϩ ⲛⲉⲙ ⲙⲉⲣⲓ.
38 Ó sì wólẹ̀ ní àkókò náà, ó sì dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run pẹ̀lú, ó sì sọ̀rọ̀ rẹ̀ fún gbogbo àwọn tí ó ń retí ìdáǹdè Jerusalẹmu.
ⲗ̅ⲏ̅⳿ⲛⲑⲱⲟⲩ ⲇⲉ ⲡⲉϫⲱⲟⲩ ϫⲉ Ⲡ⳪ ⲓⲥ ⲥⲏϥⲓ ⳿ⲥⲛⲟⲩϯ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲙⲁ ⳿ⲛⲑⲟϥ ⲇⲉ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ⲥⲉⲣⲱϣⲓ.
39 Nígbà tí wọ́n sì ti ṣe nǹkan gbogbo tán gẹ́gẹ́ bí òfin Olúwa, wọ́n padà lọ sí Galili, sí Nasareti ìlú wọn.
ⲗ̅ⲑ̅ⲟⲩⲟϩ ⲉⲧⲁⲩϫⲱⲕ ⳿ⲛϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲕⲁⲧⲁ ⳿ⲫⲛⲟⲙⲟⲥ ⳿ⲙⲠ⳪ ⲁⲩⲕⲟⲧⲟⲩ ⳿ⲉϯⲅⲁⲗⲓⲗⲉ⳿ⲁ ⳿ⲉⲧⲟⲩⲃⲁⲕⲓ ⲁⲍⲁⲣⲉⲑ.
40 Ọmọ náà sì ń dàgbà, ó sì ń lágbára, ó sì kún fún ọgbọ́n: oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run sì ń bẹ lára rẹ̀.
ⲙ̅ⲡⲓ⳿ⲁⲗⲟⲩ ⲇⲉ ⲛⲉ ⲁϥⲁⲓⲁⲓ ⲡⲉ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁϥ⳿ⲁⲙⲁϩⲓ ⲉϥⲙⲉϩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲥⲟⲫⲓ⳿ⲁ ⲟⲩⲟϩ ⲟⲩ⳿ϩⲙⲟⲧ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ ⲛⲁϥⲭⲏ ϩⲓϫⲱϥ ⲡⲉ.
41 Àwọn òbí rẹ̀ a sì máa lọ sí Jerusalẹmu ní ọdọọdún sí àjọ ìrékọjá.
ⲙ̅ⲁ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲉ ϣⲁⲩϣⲉ ⲛⲱⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲉϥⲓⲟϯ ⳿ⲛⲧⲉⲛ ⲣⲟⲙⲡⲓ ⳿ⲉ⳿ⲓⲗ̅ⲏ̅ⲙ̅ ⳿ⲉⲡⲓϣⲁⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓⲡⲁⲥⲭⲁ.
42 Nígbà tí ó sì di ọmọ ọdún méjìlá, wọ́n gòkè lọ sí Jerusalẹmu gẹ́gẹ́ bí ìṣe àjọ náà.
ⲙ̅ⲃ̅ⲟⲩⲟϩ ⲉⲧⲁϥⲉⲣⲓ̅ⲃ̅ ⳿ⲛⲣⲟⲙⲡⲓ ⲁⲩϣⲉ ⲛⲱⲟⲩ ⳿ⲉⲡⲓϣⲁⲓ ⲕⲁⲧⲁ ϯⲕⲁϩⲥ.
43 Nígbà tí ọjọ́ wọn sì pé bí wọ́n ti ń padà bọ̀, ọmọ náà, Jesu dúró lẹ́yìn ní Jerusalẹmu; Josẹfu àti ìyá rẹ̀ kò mọ̀.
ⲙ̅ⲅ̅ⲟⲩⲟϩ ⲉⲧⲁⲩϫⲱⲕ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲓ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ϧⲉⲛ ⳿ⲡϫⲓⲛⲧⲟⲩⲧⲁⲥⲑⲟ ⲁϥⲥⲱϫⲡ ⳿ⲛⲥⲱⲟⲩ ϧⲉⲛ ⳿ⲓⲗ̅ⲏ̅ⲙ̅ ⳿ⲛϫⲉ ⲓ⳿ⲁⲗⲟⲩ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲙⲡⲟⲩ⳿ⲉⲙⲓ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲉϥⲓⲟϯ.
44 Ṣùgbọ́n wọ́n ṣe bí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ èrò, wọ́n rin ìrìn ọjọ́ kan; wọ́n wá a kiri nínú àwọn ará àti àwọn ojúlùmọ̀ wọn.
ⲙ̅ⲇ̅ⲉⲩⲙⲉⲩⲓ ⲇⲉ ϫⲉ ⲛⲁϥⲙⲟϣⲓ ⲛⲉⲙ ⲛⲏⲉⲑⲙⲟϣⲓ ϩⲓ ⲡⲓⲙⲱⲓⲧ ⲁⲩ⳿ⲓ ⳿ⲛⲟⲩ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⳿ⲙⲙⲟϣⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩⲕⲱϯ ⳿ⲛⲥⲱϥ ϧⲉⲛ ⲛⲟⲩⲥⲩⲅⲅⲉⲛⲏ ⲥ ⲛⲉⲙ ⲛⲏⲉⲧⲟⲩⲥⲱⲟⲩⲛ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ.
45 Nígbà tí wọn kò sì rí i, wọ́n padà sí Jerusalẹmu, wọ́n ń wá a kiri.
ⲙ̅ⲉ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲡⲟⲩϫⲉⲙϥ ⲁⲩⲧⲁⲥⲑⲟ ⳿ⲉ⳿ⲓⲗ̅ⲏ̅ ⲙ̅ ⲉⲩⲕⲱϯ ⳿ⲛⲥⲱϥ.
46 Ó sì ṣe, lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́ta wọ́n rí i nínú tẹmpili ó jókòó ní àárín àwọn olùkọ́ni, ó ń gbọ́ tiwọn, ó sì ń bi wọ́n léèrè.
ⲙ̅ⲋ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁⲥϣⲱⲡⲓ ⲙⲉⲛⲉⲛⲥⲁ ⲅ̅ ⳿ⲛ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⲁⲩϫⲉⲙϥ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲉⲣⲫⲉⲓ ⲉϥϩⲉⲙⲥⲓ ϧⲉⲛ ⳿ⲑⲙⲏϯ ⳿ⲛⲛⲓⲣⲉϥϯ⳿ⲥⲃⲱ ⲉϥⲥⲱⲧⲉⲙ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲉϥϣⲓⲛⲓ ⲙⲙⲱⲟⲩ.
47 Ẹnu sì ya gbogbo àwọn tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀ fún òye àti ìdáhùn rẹ̀.
ⲙ̅ⲍ̅ⲛⲁⲩⲧⲱⲙⲧ ⲇⲉ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲏⲉⲧⲥⲱⲧⲉⲙ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲡⲓ⳿ⲉⲙⲓ ⲛⲉⲙ ⲧⲉϥϫⲓⲛⲉⲣⲟⲩⲱ ⲛⲱⲟⲩ.
48 Nígbà tí wọ́n sì rí i, háà ṣe wọ́n, ìyá rẹ̀ sì bi í pé, “Ọmọ, èéṣe tí ìwọ fi ṣe wá bẹ́ẹ̀? Sá wò ó, baba rẹ̀ àti èmi ti ń fi ìbànújẹ́ wá ọ kiri.”
ⲙ̅ⲏ̅ⲟⲩⲟϩ ⲧⲁⲩⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⲁⲩⲉⲣ⳿ϣⲫⲏⲣⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲡⲉϫⲉ ⲧⲉϥⲙⲁⲩ ⲛⲁϥ ϫⲉ ⲡⲁϣⲏⲣⲓ ⲟⲩ ⲡⲉ ⲫⲁⲓ ⲉⲧⲁⲕⲁⲓϥ ⲛⲁⲛ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲣⲏϯ ϩⲏⲡⲡⲉ ⲓⲥ ⲡⲉⲕⲓⲱⲧ ⲛⲉⲙ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲁⲛⲟⲓ ⳿ⲛⲉⲙⲕⲁϩ ⳿ⲛϩⲏⲧ ⲡⲉ ⲉⲛⲕⲱϯ ⳿ⲛⲥⲱⲕ.
49 Ó sì dáhùn wí fún wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń wá mi kiri? Ẹ̀yin kò mọ̀ pé èmi kò lè ṣàìmá wà níbi iṣẹ́ Baba mi?”
ⲙ̅ⲑ̅ⲟⲩⲟϩ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ⲉⲑⲃⲉⲟⲩ ⲧⲉⲧⲉⲛⲕⲱϯ ⳿ⲛⲥⲱⲓ ⲛⲁⲣⲉⲧⲉⲛ⳿ⲉⲙⲓ ⲁⲛ ⲡⲉ ϫⲉ ϩⲱϯ ⳿ⲉⲣⲟⲓ ⲛⲧⲁϣⲱⲡⲓ ϧⲉⲛ ⲛⲁ ⲡⲁⲓⲱⲧ.
50 Ọ̀rọ̀ tí o sọ kò sì yé wọn.
ⲛ̅⳿ⲛⲑⲱⲟⲩ ⲇⲉ ⳿ⲙⲡⲟⲩⲕⲁϯ ⳿ⲉⲡⲉϥⲥⲁϫⲓ ⲉⲧⲁϥϫⲟϥ ⲛⲱⲟⲩ.
51 Ó sì bá wọn sọ̀kalẹ̀ lọ sí Nasareti, sì fi ara balẹ̀ fún wọn, ṣùgbọ́n ìyá rẹ̀ pa gbogbo nǹkan wọ̀nyí mọ́ nínú ọkàn rẹ̀.
ⲛ̅ⲁ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁϥ⳿ⲓ ⳿ⲉ⳿ϧⲣⲏⲓ ⲛⲉⲙⲱⲟⲩ ⳿ⲉⲛⲁⲍⲁⲣⲉⲑ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁϥϭⲛⲟ ⳿ⲛϫⲱϥ ⲛⲱⲟⲩ ⲡⲉ ⲧⲉϥⲙⲁⲩ ⲇⲉ ⲛⲁⲥ⳿ⲁⲣⲉϩ ⳿ⲉⲛⲁⲓⲥⲁϫⲓ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⲡⲉ ϧⲉⲛ ⲡⲉⲥϩⲏⲧ.
52 Jesu sì ń pọ̀ ní ọgbọ́n, sì ń dàgbà, ó sì wà ní ojúrere ní ọ̀dọ̀ Ọlọ́run àti ènìyàn.
ⲛ̅ⲃ̅ⲟⲩⲟϩ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲛⲁϥⲉⲣ⳿ⲡⲣⲟⲕⲟⲡⲧⲓⲛ ⲡⲉ ϧⲉⲛ ϯⲙⲁⲓⲏ ⲛⲉⲙ ϯⲥⲟⲩⲫⲓ⳿ⲁ ⲛⲉⲙ ⲡⲓ⳿ϩⲙⲟⲧ ϧⲁⲧⲉⲛ ⲫϯ ⲛⲉⲙ ⲛⲓⲣⲱⲙⲓ