< Luke 2 >

1 Ó sì ṣe ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àṣẹ ti ọ̀dọ̀ Kesari Augustu jáde wá pé, kí a kọ orúkọ gbogbo ayé sínú ìwé.
О Но ангелът им рече: Не бойте се, защото, ето, благовестявам ви голяма радост, която ще бъде за всичките люде.
2 (Èyí ni ìkọ sínú ìwé èkínní tí a ṣe nígbà tí Kirene fi jẹ baálẹ̀ Siria.)
Това беше първото записване, откакто Квириний управляваше Сирия.
3 Gbogbo àwọn ènìyàn sì lọ láti kọ orúkọ wọn sínú ìwé, olúkúlùkù sí ìlú ara rẹ̀.
И всички отиваха да се записват, всеки в своя град.
4 Josẹfu pẹ̀lú sì gòkè láti Nasareti ni Galili, sí ìlú Dafidi ní Judea, tí à ń pè ní Bẹtilẹhẹmu; nítorí ti ìran àti ìdílé Dafidi ní í ṣe,
И тъй, отиде и Йосиф от Галилея, от града Назарет, в Юдея, в Давидовия град, който се нарича Витлеем, (понеже той беше от дома и рода Давидов),
5 láti kọ orúkọ rẹ̀, pẹ̀lú Maria aya rẹ̀ àfẹ́sọ́nà, tí oyún rẹ̀ ti tó bí.
за да се запише с Мария, която беше сгодена за него и беше непразна.
6 Ó sì ṣe, nígbà tí wọ́n wà níbẹ̀, ọjọ́ rẹ̀ pé tí òun yóò bí.
И когато бяха там, навършиха се дните - да роди.
7 Ó sì bí àkọ́bí rẹ̀ ọmọkùnrin, ó sì fi ọ̀já wé e, ó sì tẹ́ ẹ sínú ibùjẹ ẹran; nítorí tí ààyè kò sí fún wọn nínú ilé èrò.
И роди първородния си Син, пови Го, и положи Го в ясли, защото нямаше място за тях в страноприемницата.
8 Àwọn olùṣọ́-àgùntàn ń bẹ tí wọ́n ń gbé ní ìlú náà, wọ́n ń ṣọ́ agbo àgùntàn wọn ní òru ní pápá tí wọ́n ń gbé.
И на същото място имаше овчари, които живееха в полето, и пазеха нощна стража около стадото си.
9 Angẹli Olúwa sì yọ sí wọn, ògo Olúwa sì ràn yí wọn ká, ẹ̀rù sì bà wọ́n gidigidi.
И ангел от Господа застана пред тях, и Господната слава ги осия; и те се уплашиха много.
10 Angẹli náà sì wí fún wọn pé, “Má bẹ̀rù: sá wò ó, mo mú ìyìnrere ayọ̀ ńlá fún yín wá, tí yóò ṣe ti ènìyàn gbogbo.
Но ангелът им рече: Не бойте се, защото, ето, благовестявам ви голяма радост, която ще бъде за всичките люде.
11 Nítorí a ti bí Olùgbàlà fún yín lónìí ní ìlú Dafidi, tí í ṣe Kristi Olúwa.
Защото днес ви се роди в Давидовия град Спасител, Който е Христос Господ.
12 Èyí ni yóò sì ṣe àmì fún yín; ẹ̀yin yóò rí ọmọ ọwọ́ tí a fi ọ̀já wé, ó dùbúlẹ̀ ní ibùjẹ ẹran.”
И това ще ви бъде знакът: ще намерите Младенец, повит и лежащ в ясли.
13 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ogun ọ̀run sì darapọ̀ mọ́ angẹli náà ní òjijì, wọ́n ń yin Ọlọ́run, wí pé,
И внезапно, заедно с ангела, се намери множество небесно воинство, което хвалеше Бога, казвайки:
14 “Ògo ni fún Ọlọ́run lókè ọ̀run, àti ní ayé àlàáfíà, ìfẹ́ inú rere sí ènìyàn.”
Слава на Бога във висините. И на земята мир между човеците, в които е Неговото благоволение.
15 Ó sì ṣe, nígbà tí àwọn angẹli náà padà kúrò lọ́dọ̀ wọn lọ sí ọ̀run, àwọn olùṣọ́-àgùntàn náà bá ara wọn sọ pé, “Ẹ jẹ́ kí á lọ tààrà sí Bẹtilẹhẹmu, kí á lè rí ohun tí ó ṣẹ̀, tí Olúwa fihàn fún wa.”
Щом ангелите си отидоха от тях на небето, овчарите си рекоха един на друг: Нека отидем тогава във Витлеем, и нека видим това, що е станало, което Господ ни изяви.
16 Wọ́n sì wá lọ́gán, wọ́n sì rí Maria àti Josẹfu, àti ọmọ ọwọ́ náà, ó dùbúlẹ̀ nínú ibùjẹ ẹran.
И дойдоха бързо и намериха Мария и Йосифа, и Младенеца лежащ в яслите.
17 Nígbà tí wọ́n sì ti rí i, wọ́n sọ ohun tí a ti wí fún wọn nípa ti ọmọ yìí.
И като видяха, разказаха каквото им беше известено за това детенце.
18 Ẹnu sì ya gbogbo àwọn tí ó gbọ́ sí nǹkan wọ̀nyí tí a ti wí fún wọn láti ọ̀dọ̀ àwọn olùṣọ́-àgùntàn wá.
И всички които чуха, се зачудиха за това, което овчарите им казаха.
19 Ṣùgbọ́n Maria pa gbogbo nǹkan wọ̀nyí mọ́, ó ń rò wọ́n nínú ọkàn rẹ̀.
А Мария спазваше всички тия думи и размишляваше за тях в сърцето си.
20 Àwọn olùṣọ́-àgùntàn sì padà lọ, wọ́n ń fi ògo fún Ọlọ́run, wọ́n sì yìn ín, nítorí ohun gbogbo tí wọ́n ti gbọ́ àti tí wọ́n ti rí, bí a ti wí i fún wọn.
И овчарите се върнаха, славещи и хвалещи Бога за всичко, що бяха чули и видели, според както им беше казано.
21 Nígbà tí ọjọ́ mẹ́jọ sì pé láti kọ ọmọ náà nílà, wọ́n pe orúkọ rẹ̀ ní Jesu, bí a ti sọ ọ́ tẹ́lẹ̀ láti ọ̀dọ̀ angẹli náà wá kí á tó lóyún rẹ̀.
И като се навършиха осем дни и трябваше да обрежат Детенцето, дадоха Му името Исус, както беше наречено от ангела преди да е било зачнато в утробата.
22 Nígbà tí ọjọ́ ìwẹ̀nù Maria sì pé gẹ́gẹ́ bí òfin Mose, Josẹfu àti Maria gbé Jesu wá sí Jerusalẹmu láti fi í fún Olúwa
Като се навършиха и дните за очистването им, според Мойсеевия закон, занесоха Го в Ерусалим за да Го представят пред Господа,
23 (bí a ti kọ ọ́ sínú òfin Olúwa pé, “Gbogbo ọmọ ọkùnrin tí ó ṣe àkọ́bí, òun ni a ó pè ní mímọ́ fún Olúwa”),
(както е писано в Господния закон, че всеки първороден младенец от мъжки пол ще бъде свят на Господа),
24 àti láti rú ẹbọ gẹ́gẹ́ bí èyí tí a wí nínú òfin Olúwa: “Àdàbà méjì tàbí ọmọ ẹyẹlé méjì.”
и да принесат жертва според казаното в Господния закон две гургулици и две гълъбчета.
25 Sì kíyèsi i, ọkùnrin kan wà ní Jerusalẹmu, orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Simeoni; ọkùnrin náà sì ṣe olóòtítọ́ àti olùfọkànsìn, ó ń retí ìtùnú Israẹli, Ẹ̀mí mímọ́ sì bà lé e.
И ето, имаше в Ерусалим един човек на име Симеон; и тоя човек бе праведен и благочестив, и чакаше утехата на Израиля; и Святият Дух беше в него.
26 A sì ti fihàn án láti ọ̀dọ̀ Ẹ̀mí Mímọ́ náà wá pé, òun kì yóò rí ikú, kí ó tó rí Kristi Olúwa.
Нему бе открито от Святия Дух, че няма да види смърт, докле не види Христа Господен.
27 Ó sì ti ipa Ẹ̀mí wá sínú tẹmpili. Nígbà tí àwọn òbí rẹ̀ sì gbé Jesu wá, láti ṣe fún un bí ìṣe òfin.
И по внушението на Духа той дойде в храма; и когато родителите внесоха детенцето Исус, за да сторят за Него по обичая на закона,
28 Nígbà náà ni Simeoni gbé e ní apá rẹ̀, ó fi ìbùkún fún Ọlọ́run, ó ní:
той Го взе на ръцете си и благослови Бога, като каза:
29 “Olúwa Olódùmarè, nígbà yìí ni ó tó jọ̀wọ́ ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ lọ́wọ́ lọ, ní àlàáfíà, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Сега, Владико, отпущаш слугата Си в мир, според думата си;
30 Nítorí tí ojú mi ti rí ìgbàlà rẹ ná,
защото видяха очите ми спасението,
31 tí ìwọ ti pèsè sílẹ̀ níwájú ènìyàn gbogbo;
което си приготвил пред всички люде;
32 ìmọ́lẹ̀ láti mọ́ sí àwọn aláìkọlà, àti ògo Israẹli ènìyàn rẹ̀.”
светлина да просвещава народите. И слава на Твоите люде Израил.
33 Ẹnu sì ya Josẹfu àti ìyá rẹ̀ sí nǹkan tí a ń sọ sí i wọ̀nyí.
А баща Му и майка Му се чудеха на това, което се говореше за Него.
34 Simeoni sì súre fún wọn, ó sì wí fún Maria ìyá rẹ̀ pé, “Kíyèsi i, a gbé ọmọ yìí kalẹ̀ fún ìṣubú àti ìdìde ọ̀pọ̀ ènìyàn ní Israẹli; àti fún àmì tí a ń sọ̀rọ̀-òdì sí;
И Симеон го благослови, и рече на майка Му Мария: Ето, това детенце е поставено за падане и за ставане на мнозина в Израиля, и за белег, против който ще се говори.
35 (idà yóò sì gún ìwọ náà ní ọkàn pẹ̀lú) kí á lè fi ìrònú ọ̀pọ̀ ọkàn hàn.”
Да! И на сама тебе меч ще прониже душата ти, за да се открият помислите на много сърца.
36 Ẹnìkan sì ń bẹ, Anna wòlíì, ọmọbìnrin Penueli, nínú ẹ̀yà Aṣeri: ọjọ́ ogbó rẹ̀ pọ̀, ó ti bá ọkọ gbé ní ọdún méje láti ìgbà wúńdíá rẹ̀ wá;
Имаше и някоя си Анна, Фануилова дъщеря, от Асировото племе; (тя беше в много напреднала възраст, като бе живяла с мъжа си седем години от девството си.
37 Ó sì ṣe opó títí ó fi di ẹni ọdún mẹ́rìnlélọ́gọ́rin, ẹni tí kò kúrò ní tẹmpili, ṣùgbọ́n ó ń fi àwẹ̀ àti àdúrà sin Ọlọ́run lọ́sàn án àti lóru.
И беше вдовица за цели осемдесет и четири години), която не се отделяше от храма, дето нощем и денем служеше Богу в пост и молитва.
38 Ó sì wólẹ̀ ní àkókò náà, ó sì dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run pẹ̀lú, ó sì sọ̀rọ̀ rẹ̀ fún gbogbo àwọn tí ó ń retí ìdáǹdè Jerusalẹmu.
И тя, като се приближи, в същия час, благодареше Богу, и говореше за Него на всички, които ожидаха изкуплението на Ерусалим.
39 Nígbà tí wọ́n sì ti ṣe nǹkan gbogbo tán gẹ́gẹ́ bí òfin Olúwa, wọ́n padà lọ sí Galili, sí Nasareti ìlú wọn.
И като свършиха всичко, що беше според Господния закон, върнаха се в Галилея, в града си Назарет.
40 Ọmọ náà sì ń dàgbà, ó sì ń lágbára, ó sì kún fún ọgbọ́n: oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run sì ń bẹ lára rẹ̀.
А Детенцето растеше, крепнеше, и се изпълваше с мъдрост; и Божията благодат бе на Него.
41 Àwọn òbí rẹ̀ a sì máa lọ sí Jerusalẹmu ní ọdọọdún sí àjọ ìrékọjá.
И родителите Му ходеха всяка година в Ерусалим за празника на Пасхата.
42 Nígbà tí ó sì di ọmọ ọdún méjìlá, wọ́n gòkè lọ sí Jerusalẹmu gẹ́gẹ́ bí ìṣe àjọ náà.
И когато Той беше на дванадесет години, като отидоха по обичая на празника,
43 Nígbà tí ọjọ́ wọn sì pé bí wọ́n ti ń padà bọ̀, ọmọ náà, Jesu dúró lẹ́yìn ní Jerusalẹmu; Josẹfu àti ìyá rẹ̀ kò mọ̀.
и като изкараха дните и се връщаха, Момчето Исус остана в Ерусалим, без да знаят родителите Му.
44 Ṣùgbọ́n wọ́n ṣe bí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ èrò, wọ́n rin ìrìn ọjọ́ kan; wọ́n wá a kiri nínú àwọn ará àti àwọn ojúlùmọ̀ wọn.
А те, понеже мислеха, че Той е с дружината, изминаха един ден път, като Го търсеха между роднините и познатите си.
45 Nígbà tí wọn kò sì rí i, wọ́n padà sí Jerusalẹmu, wọ́n ń wá a kiri.
И като не Го намериха, върнаха се в Ерусалим и Го търсеха.
46 Ó sì ṣe, lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́ta wọ́n rí i nínú tẹmpili ó jókòó ní àárín àwọn olùkọ́ni, ó ń gbọ́ tiwọn, ó sì ń bi wọ́n léèrè.
И след три дни Го намериха в храма, седнал между законоучителите, че ги слушаше и ги запитваше.
47 Ẹnu sì ya gbogbo àwọn tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀ fún òye àti ìdáhùn rẹ̀.
И всички, които Го слушаха, се учудваха на разума Му и на отговорите Му.
48 Nígbà tí wọ́n sì rí i, háà ṣe wọ́n, ìyá rẹ̀ sì bi í pé, “Ọmọ, èéṣe tí ìwọ fi ṣe wá bẹ́ẹ̀? Sá wò ó, baba rẹ̀ àti èmi ti ń fi ìbànújẹ́ wá ọ kiri.”
И като Го видяха, смаяха се; и рече Му майка Му: Синко, защо постъпи тъй с нас? Ето, баща Ти и аз, наскърбени, Те търсехме.
49 Ó sì dáhùn wí fún wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń wá mi kiri? Ẹ̀yin kò mọ̀ pé èmi kò lè ṣàìmá wà níbi iṣẹ́ Baba mi?”
А Той им рече: Защо да Ме търсите? Не знаете ли, че трябва да се намеря около дома на Отца Ми?
50 Ọ̀rọ̀ tí o sọ kò sì yé wọn.
А те не разбраха думата, която им рече.
51 Ó sì bá wọn sọ̀kalẹ̀ lọ sí Nasareti, sì fi ara balẹ̀ fún wọn, ṣùgbọ́n ìyá rẹ̀ pa gbogbo nǹkan wọ̀nyí mọ́ nínú ọkàn rẹ̀.
И Той слезе с тях, и дойде в Назарет, и там им се покоряваше. А майка Му спазваше всички тия думи в сърцето си.
52 Jesu sì ń pọ̀ ní ọgbọ́n, sì ń dàgbà, ó sì wà ní ojúrere ní ọ̀dọ̀ Ọlọ́run àti ènìyàn.
А Исус напредваше в мъдрост, в ръст и в благоволение пред Бога и човеците.

< Luke 2 >