< Luke 19 >

1 Jesu sì wọ Jeriko lọ, ó sì ń kọjá láàrín rẹ̀.
Ezután Jerikóba ért, és átment rajta.
2 Sì kíyèsi i, ọkùnrin kan wà tí a ń pè ní Sakeu, ó sì jẹ́ olórí agbowó òde kan, ó sì jẹ́ ọlọ́rọ̀.
Íme, volt ott egy ember, akit Zákeusnak hívtak, aki fővámszedő volt és gazdag.
3 Ó sì ń fẹ́ láti rí ẹni tí Jesu jẹ́: kò sì lè rí i, nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn, àti nítorí tí òun jẹ́ ènìyàn kúkúrú.
Igyekezett meglátni Jézust, hogy ki az, de a sokaságtól nem láthatta meg, mert kis termetű ember volt.
4 Ó sì súré síwájú, ó gun orí igi sikamore kan, kí ó bà lè rí i: nítorí tí yóò kọjá lọ níhà ibẹ̀.
Ezért előrefutott, és felmászott egy eperfügefára, hogy lássa őt, mert arra kellett elmennie.
5 Nígbà tí Jesu sì dé ibẹ̀, ó gbé ojú sókè, ó sì rí i, ó sì wí fún un pé, “Sakeu! Yára, kí o sì sọ̀kalẹ̀; nítorí pé èmi yóò wọ ilé rẹ lónìí.”
Amikor arra a helyre jutott, Jézus feltekintett, és meglátta, és ezt mondta neki: „Zákeus, hamar jöjj le, mert ma nekem a te házadnál kell megszállnom.“
6 Ó sì yára, ó sọ̀kalẹ̀, ó sì fi ayọ̀ gbà á.
Ekkor sietve leszállt, és örömmel befogadta.
7 Nígbà tí wọ́n sì rí i, gbogbo wọn ń kùn, wí pé, “Ó lọ bá ọkùnrin ẹlẹ́ṣẹ̀ náà ní àlejò.”
Amikor ezt látták, mindnyájan zúgolódtak, és ezt mondták: „Bűnös emberhez ment be szállásra.“
8 Sakeu sì dìde, ó sì wí fún Olúwa pé, “Wò ó, Olúwa, ààbọ̀ ohun ìní mi ni mo fi fún tálákà; bí mo bá sì fi èké gba ohun kan lọ́wọ́ ẹnikẹ́ni, èmi san án padà ní ìlọ́po mẹ́rin!”
Zákeus pedig előállt, ezt mondta az Úrnak: „Uram, íme, minden vagyonomnak felét a szegényeknek adom, és ha valakitől valamit kizsaroltam, négyszer annyit adok helyébe.“
9 Jesu sì wí fún un pé, “Lónìí ni ìgbàlà wọ ilé yìí, níwọ̀n bí òun pẹ̀lú ti jẹ́ ọmọ Abrahamu.
Jézus ezt mondta neki: „Ma lett üdvössége ennek a háznak, mert ő is Ábrahám fia.
10 Nítorí Ọmọ Ènìyàn dé láti wá àwọn tí ó nù kiri, àti láti gbà wọ́n là.”
Mert azért jött az Emberfia, hogy megkeresse és megtartsa, ami elveszett.“
11 Nígbà tí wọ́n sì ń gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, ó sì tẹ̀síwájú láti pa òwe kan, nítorí tí ó súnmọ́ Jerusalẹmu, àti nítorí tí wọn ń rò pé, ìjọba Ọlọ́run yóò farahàn nísinsin yìí.
Amikor pedig ezeket hallották, még egy példázatot is mondott, mert közel volt Jeruzsálemhez, és azok azt gondolták, hogy azonnal megjelenik Isten országa.
12 Ó sì wí pé, “Ọkùnrin ọlọ́lá kan lọ sí ìlú òkèrè láti gba ìjọba kí ó sì padà.
Ezt mondta tehát: „Egy nemesember egy messzi tartományba ment, hogy ott királyságot szerezzen magának, azután majd visszatérjen.
13 Ó sì pe àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ mẹ́wàá, ó fi owó mina mẹ́wàá fún wọn, ó sì wí fún wọn pé, ‘Ẹ máa ṣòwò títí èmi ó fi dé!’
Hívatta azért tíz szolgáját, és adott nekik tíz minát, és ezt mondta nekik: Kereskedjetek, amíg visszajövök.
14 “Ṣùgbọ́n àwọn ará ìlù rẹ̀ kórìíra rẹ̀, wọ́n sì rán ikọ̀ tẹ̀lé e, wí pé, ‘Àwa kò fẹ́ kí ọkùnrin yìí jẹ ọba lórí wa.’
Alattvalói pedig gyűlölték őt, és követséget küldtek utána, és ezt üzenték: Nem akarjuk, hogy ő uralkodjék rajtunk.
15 “Nígbà tí ó gba ìjọba tan, tí ó padà dé, ó pàṣẹ pé, kí a pe àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ wọ̀nyí tí òun ti fi owó fún wá sọ́dọ̀ rẹ̀, nítorí kí ó le mọ iye èrè tí olúkúlùkù ti jẹ nínú iṣẹ́ òwò wọn.
Történt, amikor megszerezte a királyságot, megparancsolta, hogy szolgáit, akiknek a pénzt adta, hívják oda hozzá, hogy megtudja, ki mint kereskedett.
16 “Èyí èkínní sì wá, ó wí pé, ‘Olúwa, owó mina rẹ jèrè owó mina mẹ́wàá sí i.’
Eljött az első, és ezt mondta: Uram, a te minád tíz minát nyert.
17 “Olúwa rẹ̀ sì wí fún un pé, ‘O ṣeun, ìwọ ọmọ ọ̀dọ̀ rere! Nítorí tí ìwọ ṣe olóòtítọ́ ní ohun kínkínní, gba àṣẹ lórí ìlú mẹ́wàá.’
Ő pedig ezt mondta neki: Jól van, jó szolgám, mivel hű voltál a kevesen, legyen hatalmad tíz város felett.
18 “Èyí èkejì sì wá, ó wí pé, ‘Olúwa, owó mina rẹ jèrè owó mina márùn.’
És jött a második, és ezt mondta: Uram, a te minád öt minát nyert.
19 “Olúwa rẹ sì wí fún un pẹ̀lú pé, ‘Ìwọ pẹ̀lú joyè ìlú márùn-ún!’
Így szólt ennek is: Neked is legyen hatalmad öt város felett.
20 “Òmíràn sì wá, ó wí pé, ‘Olúwa, wò ó owó mina rẹ tí ń bẹ lọ́wọ́ mi ni mo dì sínú aṣọ pélébé kan;
És eljött a harmadik is, és ezt mondta: Uram itt van a te minád, amelyet kendőbe kötve tartottam.
21 nítorí mo bẹ̀rù rẹ, àti nítorí tí ìwọ ṣe òǹrorò ènìyàn, ìwọ a máa mú èyí tí ìwọ kò fi lélẹ̀, ìwọ a sì máa ká èyí tí ìwọ kò gbìn!’
Mert féltem tőled, mert kemény ember vagy, azt is elveszed, amit nem te tettél el, és learatod, amit nem te vetettél.
22 “Olúwa rẹ sì wí fún un pé, ‘Ní ẹnu ara rẹ náà ni èmi ó ṣe ìdájọ́ rẹ, ìwọ ọmọ ọ̀dọ̀ búburú, ìwọ mọ̀ pé òǹrorò ènìyàn ni mí, pé, èmi a máa mú èyí tí èmi kò fi lélẹ̀ èmi a sì máa ká èyí tí èmi kò gbìn.
Ezt mondta annak: A te szavaid szerint ítéllek meg téged, gonosz szolga. Tudtad, hogy én kemény ember vagyok, aki elveszem, amit nem én tettem el, és learatom, amit nem én vetettem.
23 Èéha sì ti ṣe tí ìwọ kò fi owó mi pamọ́ sí ilé ìfowópamọ́, pé nígbà tí mo bá dé, èmi ìbá ti béèrè rẹ̀ pẹ̀lú èlé?’
Miért nem tetted azért az én pénzemet a pénzváltók asztalára, hogy amikor megjövök, kamatostul kapjam vissza?
24 “Ó sì wí fún àwọn tí ó dúró létí ibẹ̀ pé, ‘Ẹ gba owó mina náà lọ́wọ́ rẹ̀, kí ẹ sì fi í fún ẹni tí ó ní owó mina mẹ́wàá.’
Az ott állóknak ezt mondta: Vegyétek el ettől a minát, és adjátok annak, akinek tíz minája van.
25 “Wọ́n sì wí fún un pé, ‘Olúwa, ó ní owó mina mẹ́wàá.’
És mondták neki: Uram, annak már van tíz minája!
26 “Mo wí fún yín pé, ‘Ẹnikẹ́ni tí ó ní, ni a ó fi fún, àti lọ́dọ̀ ẹni tí kò ní èyí tí ó ní pàápàá a ó gbà á lọ́wọ́ rẹ̀.
De ő ezt mondta: Mondom nektek, hogy mindenkinek, akinek van, adatik, akinek pedig nincs, még amije van, az is elvétetik tőle.
27 Ṣùgbọ́n àwọn ọ̀tá mi wọ̀nyí, tí kò fẹ́ kí èmi jẹ ọba lórí wọn ẹ mú wọn wá ìhín yìí, kí ẹ sì pa wọ́n níwájú mi!’”
Ellenségeimet pedig, akik nem akarták, hogy rajtuk uralkodjam, hozzátok ide, és öljétek meg előttem.“
28 Nígbà tí ó sì ti wí nǹkan wọ̀nyí tan, ó lọ síwájú, ó ń gòkè lọ sí Jerusalẹmu.
Miután ezeket elmondta, továbbment Jeruzsálem felé.
29 Ó sì ṣe, nígbà tí ó súnmọ́ Betfage àti Betani ní òkè tí a ń pè ní òkè olifi, ó rán àwọn méjì nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀.
És történt, hogy amikor Betfagéhoz és Betániához közeledett, a hegynél, amelyet Olajfák hegyének neveznek, elküldött kettőt tanítványai közül,
30 Wí pé, “Ẹ lọ sí ìletò tí ó kọjú sí yín; nígbà tí ẹ̀yin bá wọ̀ ọ́ lọ, ẹ̀yin ó rí ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan tí a so, tí ẹnikẹ́ni kò gùn rí, ẹ tú u, kí ẹ sì fà á wá.
és ezt mondta nekik: „Menjetek el az átellenben lévő faluba, amelybe beérve találtok egy megkötött szamárcsikót, amelyen még ember nem ült, oldjátok el, és hozzátok ide.
31 Bí ẹnikẹ́ni bá sì bi yín pé, ‘Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń tú u?’ Kí ẹ̀yin wí báyìí pé, ‘Olúwa ń fẹ́ lò ó.’”
Ha pedig valaki megkérdezi, hogy miért oldjátok el, ezt mondjátok annak: Az Úrnak van szüksége rá.“
32 Àwọn tí a rán sì mú ọ̀nà wọn pọ̀n, wọ́n sì bá a gẹ́gẹ́ bí ó ti wí fún wọn.
A küldöttek elmentek, és mindent úgy találtak, amint megmondta nekik.
33 Bí wọ́n sì ti ń tú ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà, àwọn Olúwa rẹ̀ bi wọ́n pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń tu kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà?”
Amikor a szamárcsikót eloldották, annak gazdái ezt mondták: „Miért oldjátok el a szamárcsikót?“
34 Wọ́n sì wí pé, “Olúwa fẹ́ lò ó.”
Ők pedig ezt mondták: „Az Úrnak van szüksége rá.“
35 Wọ́n sì fà á tọ Jesu wá, wọ́n sì tẹ́ aṣọ sí ẹ̀yìn ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà, wọ́n sì gbé Jesu kà á.
Elvitték azért azt Jézushoz, és felsőruhájukat a szamárcsikóra tették, és felültették rá Jézust.
36 Bí ó sì ti ń lọ wọ́n tẹ́ aṣọ wọn sí ọ̀nà.
Amint tovább ment, az emberek felsőruhájukat az útra terítették.
37 Bí ó sì ti súnmọ́ etí ibẹ̀ ní gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè olifi, gbogbo àwọn ọmọ-ẹ̀yìn bẹ̀rẹ̀ sí í yọ̀, wọ́n sì fi ohùn rara yin Ọlọ́run, nítorí iṣẹ́ ńlá gbogbo tí wọ́n ti rí,
Amikor már az Olajfák lejtőjéhez közeledett, a tanítványok egész sokasága örvendezve, fennhangon kezdte dicsérni Istent mindazokért a csodákért, amelyeket láttak,
38 wí pé, “Olùbùkún ni ọba tí ó ń bọ̀ wá ní orúkọ Olúwa!” “Àlàáfíà ní ọ̀run, àti ògo ni òkè ọ̀run!”
és ezt mondták: „Áldott a Király, aki az Úr nevében jön! Békesség a mennyben, és dicsőség a magasságban!“
39 Àwọn kan nínú àwọn Farisi nínú àwùjọ náà sì wí fún un pé, “Olùkọ́ bá àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ wí.”
A sokaságból néhány farizeus ezt mondta neki: „Mester, utasítsd rendre tanítványaidat!“
40 Ó sì dá wọn lóhùn, ó wí fún wọn pé, “Mo wí fún yín, bí àwọn wọ̀nyí bá pa ẹnu wọn mọ́, àwọn òkúta yóò kígbe sókè.”
Ő így válaszolt nekik: „Mondom nektek, ha ezek elhallgatnak, a kövek fognak kiáltani.“
41 Nígbà tí ó sì súnmọ́ etílé, ó síjú wo ìlú náà, ó sọkún sí i lórí,
Amikor közelebb ért, és meglátta a várost, megsiratta azt.
42 Ó ń wí pé, “Ìbá ṣe pé ìwọ mọ̀, lónìí yìí, àní ìwọ, ohun tí í ṣe tí àlàáfíà rẹ! Ṣùgbọ́n nísinsin yìí wọ́n pamọ́ kúrò lójú rẹ.
Ezt mondta: „Bár felismerted volna ezen a napon te is, ami békességedre szolgál. Most azonban el van rejtve szemed elől.
43 Nítorí ọjọ́ ń bọ̀ fún ọ, tí àwọn ọ̀tá rẹ yóò mọ odi bèbè yí ọ ká, àní tí wọn yóò sì yí ọ ká, wọn ó sì ká ọ mọ́ níhà gbogbo.
Mert jönnek majd rád napok, amikor ellenségeid körülötted sáncot építenek, körülvesznek, és mindenfelől szorongatnak;
44 Wọn ó sì wó ọ palẹ̀ ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ pẹ̀lú rẹ; wọn kì yóò sì fi òkúta kan sílẹ̀ lórí ara wọn; nítorí ìwọ kò mọ ọjọ́ ìbẹ̀wò rẹ.”
a földre tipornak téged és fiaidat, és nem hagynak benned követ kövön, mert nem ismerted fel meglátogatásod idejét.“
45 Ó sì wọ inú tẹmpili lọ, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí lé àwọn tí ń tà nínú rẹ̀ sóde;
Azután bement a templomba, és kezdte kiűzni azokat, akik ott adnak és vesznek,
46 Ó sì wí fún wọn pé, “A ti kọ̀wé rẹ̀ pé, ‘Ilé mi yóò jẹ́ ilé àdúrà?’ Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti sọ ọ́ di ihò àwọn ọlọ́ṣà.”
és ezt mondta nekik: „Meg van írva: »Az én házam imádságnak háza, ti pedig azt latrok barlangjává tettétek.«“
47 Ó sì ń kọ́ni lójoojúmọ́ ní tẹmpili, ṣùgbọ́n àwọn olórí àlùfáà, àti àwọn akọ̀wé, àti àwọn olórí àwọn ènìyàn ń wá ọ̀nà láti pa á.
Aztán naponként tanított a templomban. A főpapok, az írástudók és a nép előkelői azon voltak, hogy elpusztítsák.
48 Wọn kò sì rí nǹkan kan tí wọn ìbá ṣe; nítorí gbogbo ènìyàn ṣù mọ́ ọn láti gbọ́rọ̀ rẹ̀.
De nem találtak megoldást arra, hogy mit cselekedjenek, mert az egész nép rajongva hallgatta őt.

< Luke 19 >