< Luke 18 >
1 Ó sì pa òwe kan fún wọn láti fi yé wọn pe, ó yẹ kí a máa gbàdúrà nígbà gbogbo, kí a má sì ṣàárẹ̀.
I powiedział im jeszcze podobieństwo do tego zmierzające, iż się zawsze potrzeba modlić, a nie ustawać,
2 Wí pé, “Onídàájọ́ kan wà ní ìlú kan, tí kò bẹ̀rù Ọlọ́run, tí kò sì ṣe ojúsàájú ènìyàn.
Mówiąc: Był niektóry sędzia w jednem mieście, który się Boga nie bał, i człowieka się nie wstydził.
3 Opó kan sì wà ní ìlú náà, ó sì ń tọ̀ ọ́ wá, wí pé, ‘Gbẹ̀san mi lára ọ̀tá mi!’
Była też wdowa w temże mieście, która przychodziła do niego, mówiąc: Pomścij się krzywdy mojej nad przeciwnikiem moim.
4 “Lákọ̀ọ́kọ́ kò dá a lóhùn, ṣùgbọ́n níkẹyìn ó wí nínú ara rẹ̀ pé, ‘Bí èmi kò tilẹ̀ bẹ̀rù Ọlọ́run, tí èmi kò sì ṣe ojúsàájú ènìyàn,
Lecz on długo nie chciał. Ale potem rzekł sam w sobie: Aczci się Boga nie boję i człowieka się nie wstydzę,
5 Ṣùgbọ́n nítorí tí opó yìí ń yọ mí lẹ́nu, èmi ó gbẹ̀san rẹ̀, kí ó má ba à fi wíwá rẹ̀ nígbàkígbà dá mi lágara.’”
Wszakże iż mi się uprzykrza ta wdowa, pomszczę się krzywdy jej, aby na ostatek przyszedłszy, nie była mi ciężką.
6 Olúwa sì wí pé, “Ẹ gbọ́ bí aláìṣòótọ́ onídàájọ́ ti wí!
Rzekł tedy Pan: Słuchajcież, co mówi niesprawiedliwy sędzia.
7 Ọlọ́run kì yóò ha sì gbẹ̀san àwọn àyànfẹ́ rẹ̀, tí ń fi ọ̀sán àti òru kígbe pè é, tí ó sì mú sùúrù fún wọn?
A Bóg izali się nie pomści krzywdy wybranych swoich, wołających do siebie we dnie i w nocy, chociaż im długo cierpi?
8 Mo wí fún yín, yóò gbẹ̀san wọn kánkán! Ṣùgbọ́n nígbà tí Ọmọ Ènìyàn bá dé yóò ha rí ìgbàgbọ́ ní ayé bí?”
Powiadam wam, iż się pomści krzywdy ich w rychle. Ale gdy przyjdzie Syn człowieczy, izali znajdzie wiarę na ziemi?
9 Ó sì pa òwe yìí fún àwọn kan tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé ara wọn pé, àwọn ni olódodo, tí wọ́n sì ń gan àwọn ẹlòmíràn,
Rzekł też i do niektórych, którzy ufali sami w sobie, że byli sprawiedliwymi, a inszych za nic nie mieli, to podobieństwo:
10 pé, “Àwọn ọkùnrin méjì gòkè lọ sí tẹmpili láti gbàdúrà, ọ̀kan jẹ́ Farisi, èkejì sì jẹ́ agbowó òde.
Dwoje ludzi wstąpiło do kościoła, aby się modlili, jeden Faryzeusz a drugi celnik.
11 Èyí Farisi dìde, ó sì ń gbàdúrà nínú ara rẹ̀ báyìí pé, ‘Ọlọ́run mo dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ, nítorí tí èmi kò rí bí àwọn ará ìyókù, àwọn alọ́nilọ́wọ́gbà, aláìṣòótọ́, panṣágà, tàbí bí agbowó òde yìí.
Faryzeusz stanąwszy, tak się sam u siebie modlił: Dziękuję tobie, Boże! żem nie jest jako inni ludzie, drapieżni, niesprawiedliwi, cudzołożnicy, albo jako i ten celnik.
12 Èmi ń gbààwẹ̀ lẹ́ẹ̀méjì ní ọ̀sẹ̀, mo ń san ìdámẹ́wàá ohun gbogbo tí mo ní.’
Poszczę dwakroć w tydzień; daję dziesięcinę ze wszystkiego, co mam.
13 “Ṣùgbọ́n agbowó òde dúró lókèèrè, kò tilẹ̀ jẹ́ gbé ojú rẹ̀ sókè ọ̀run, ṣùgbọ́n ó lu ara rẹ̀ ní oókan àyà, ó wí pé, ‘Ọlọ́run ṣàánú fún mi, èmi ẹlẹ́ṣẹ̀!’
A celnik stojąc z daleka, nie chciał podnieść i oczu swych w niebo, ale się bił w piersi swoje, mówiąc: Boże! bądź miłościw mnie grzesznemu.
14 “Mo wí fún yín, ọkùnrin yìí sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ̀ ní ìdáláre ju èkejì lọ: nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá gbé ara rẹ̀ ga, òun ni a ó rẹ̀ sílẹ̀; ẹni tí ó bá sì rẹ̀ ara rẹ̀ sílẹ̀ òun ni a ó gbéga.”
Powiadam wam, żeć ten odszedł usprawiedliwionym do domu swego, więcej niżeli on: albowiem kto się wywyższa, będzie poniżony, a kto się poniża, będzie wywyższony.
15 Wọ́n sì gbé àwọn ọmọ ọwọ́ tọ̀ ọ́ wá pẹ̀lú, kí ó lè gbé ọwọ́ lé wọn; ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ rí i, wọ́n ń bá wọn wí.
Przynoszono też do niego i niemowlątka, aby się ich dotykał; co gdy widzieli uczniowie, gromili je.
16 Ṣùgbọ́n Jesu pè wọ́n sọ́dọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé, “Ẹ jẹ́ kí àwọn ọmọ kékeré wá sọ́dọ̀ mi, ẹ má sì ṣe dá wọn lẹ́kun, nítorí tí irú wọn ni ìjọba Ọlọ́run.
Ale Jezus zwoławszy ich, rzekł: Dopuśćcie dziatkom przychodzić do mnie, a nie zabraniajcie im; albowiem takowych jest królestwo Boże.
17 Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ẹnikẹ́ni tí kò bá gbà ìjọba Ọlọ́run bí ọmọ kékeré, kì yóò wọ inú rẹ̀ bí ó ti wù kí ó rí.”
Zaprawdę powiadam wam: Ktobykolwiek nie przyjął królestwa Bożego jako dzieciątko, nie wnijdzie do niego.
18 Ìjòyè kan sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, wí pé, “Olùkọ́ rere, kín ni èmi ó ṣe tí èmi ó fi jogún ìyè àìnípẹ̀kun?” (aiōnios )
I pytał go niektóry książę, mówiąc: Nauczycielu dobry! co czyniąc odziedziczę żywot wieczny? (aiōnios )
19 Jesu wí fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń pè mí ní ẹni rere? Ẹni rere kan kò sí bí kò ṣe ẹnìkan, èyí sì ni Ọlọ́run.
I rzekł mu Jezus: Przecz mię zowiesz dobrym? Nikt nie jest dobry, tylko jeden, to jest Bóg.
20 Ìwọ mọ̀ àwọn òfin: ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe panṣágà, ìwọ kò gbọdọ̀ pànìyàn, ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe jalè, ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe jẹ́rìí èké, bọ̀wọ̀ fún baba àti ìyá rẹ.’”
Umiesz przykazania? Nie cudzołóż, nie zabijaj, nie kradnij, nie świadcz fałszywie, czcij ojca twego i matkę twoję.
21 Ó sì wí pé, “Gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni èmi ti pamọ́ láti ìgbà èwe mi wá.”
A on rzekł: Tegom wszystkiego przestrzegał od młodości mojej.
22 Nígbà tí Jesu sì gbọ́ èyí, ó wí fún un pé, “Ohun kan ni ó kù fún ọ síbẹ̀: lọ ta ohun gbogbo tí o ní, kí o sì pín in fún àwọn tálákà, ìwọ ó sì ní ìṣúra ní ọ̀run: sì wá, kí o máa tọ̀ mí lẹ́yìn.”
Co usłyszawszy Jezus, rzekł mu: Jednego ci jeszcze nie dostaje; wszystko, co masz, sprzedaj, a rozdaj ubogim, a będziesz miał skarb w niebie; a przyszedłszy naśladuj mię.
23 Nígbà tí ó sì gbọ́ èyí, inú rẹ̀ bàjẹ́ gidigidi, nítorí tí ó ní ọrọ̀ púpọ̀.
A on usłyszawszy to, bardzo się zasmucił; bo był nader bogaty.
24 Nígbà tí Jesu rí i pé inú rẹ̀ bàjẹ́ gidigidi, ó wí pé, “Yóò ti ṣòro tó fún àwọn tí ó ní ọrọ̀ láti wọ ìjọba Ọlọ́run!
A gdy go Jezus ujrzał bardzo zasmuconego, rzekł: Jakoż trudno ci, co mają pieniądze, wnijdą do królestwa Bożego!
25 Nítorí ó rọrùn fún ìbákasẹ láti gba ojú abẹ́rẹ́ wọlé jù fún ọlọ́rọ̀ láti wọ ìjọba Ọlọ́run lọ.”
Albowiem łatwiej jest wielbłądowi przejść przez ucho igielne, niż bogatemu wnijść do królestwa Bożego.
26 Àwọn tí ó sì gbọ́ wí pé, “Ǹjẹ́ ta ni ó ha lè là?”
Tedy rzekli ci, którzy to słyszeli: I któż może być zbawiony?
27 Ó sì wí pé, “Ohun tí ó ṣòro lọ́dọ̀ ènìyàn kò ṣòro lọ́dọ̀ Ọlọ́run.”
Ale on rzekł: Co jest niemożebne u ludzi, możebne jest u Boga.
28 Peteru sì wí pé, “Sá wò ó, àwa ti fi ilé wa sílẹ̀, a sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn!”
I rzekł Piotr: Otośmy my opuścili wszystko, a poszliśmy za tobą.
29 Ó sì wí fún wọn pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, kò sí ẹni tí ó fi ilé, tàbí aya, tàbí ará, tàbí òbí, tàbí ọmọ sílẹ̀, nítorí ìjọba Ọlọ́run,
Tedy im on rzekł: Zaprawdę powiadam wam, iż nie masz nikogo, co by opuścił dom, albo rodziców, albo braci, albo żonę, albo dzieci dla królestwa Bożego,
30 tí kì yóò gba ìlọ́po púpọ̀ sí i ní ayé yìí, àti ní ayé tí ń bọ̀ ìyè àìnípẹ̀kun.” (aiōn , aiōnios )
Aby nie wziął daleko więcej w tym czasie, a w przyszłym wieku żywota wiecznego. (aiōn , aiōnios )
31 Nígbà náà ni ó pe àwọn méjìlá sọ́dọ̀ rẹ̀, ó sì wí fún wọn pé, “Sá wò ó, àwa ń gòkè lọ sí Jerusalẹmu, a ó sì mú ohun gbogbo ṣẹ, tí a ti kọ láti ọwọ́ àwọn wòlíì, nítorí Ọmọ Ènìyàn.
A wziąwszy z sobą onych dwunastu, rzekł im: Oto wstępujemy do Jeruzalemu, a wypełni się wszystko, co napisano przez proroki o Synu człowieczym.
32 Nítorí tí a ó fi lé àwọn aláìkọlà lọ́wọ́, a ó fi ṣe ẹlẹ́yà, a ó sì fi ṣe ẹ̀sín, a ó sì tutọ́ sí i lára.
Bo będzie wydany poganom, i będzie naśmiewany, i zelżony, i uplwany:
33 Wọn ó sì nà án, wọn ó sì pa á, ní ọjọ́ kẹta yóò sì jíǹde.”
A ubiczowawszy zabiją go; ale dnia trzeciego zmartwychwstanie.
34 Ọ̀kan nínú nǹkan wọ̀nyí kò sì yé wọn, ọ̀rọ̀ yìí sì pamọ́ fún wọn, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì mọ ohun tí a wí.
Lecz oni z tego nic nie zrozumieli, i było to słowo zakryte przed nimi, i nie wiedzieli, co mówiono.
35 Bí ó ti súnmọ́ Jeriko, afọ́jú kan jókòó lẹ́bàá ọ̀nà ó ń ṣagbe.
I stało się, gdy się on przybliżał do Jerycha, ślepy niektóry siedział podle drogi, żebrząc.
36 Nígbà tí ó gbọ́ tí ọ̀pọ̀ ń kọjá lọ, ó béèrè pé, kín ni ìtumọ̀ èyí.
A usłyszawszy lud przechodzący, pytał, co by to było?
37 Wọ́n sì wí fún un pé, “Jesu ti Nasareti ni ó ń kọjá lọ.”
I powiedziano mu, iż Jezus Nazareński tędy idzie.
38 Ó sì kígbe pé, “Jesu, ìwọ ọmọ Dafidi, ṣàánú fún mi!”
I zawołał, mówiąc: Jezusie, Synu Dawidowy! zmiłuj się nade mną.
39 Àwọn tí ń lọ níwájú bá a wí, pé, kí ó pa ẹnu rẹ̀ mọ́, ṣùgbọ́n òun sì kígbe sókè sí í pé, “Ìwọ Ọmọ Dafidi, ṣàánú fún mi!”
Lecz ci, co szli wprzód, gromili go, aby milczał. Ale on tem więcej wołał: Synu Dawidowy! zmiłuj się nade mną.
40 Jesu sì dúró, ó ní, kí á mú un tọ òun wá nígbà tí ó sì súnmọ́ ọn, ó bi í
Zastanowiwszy się tedy Jezus, kazał go przywieść do siebie; a gdy się przybliżył, pytał go, mówiąc:
41 wí pé, “Kí ni ìwọ ń fẹ́ kí èmi ṣe fún ọ?” Ó sì wí pé, “Olúwa jẹ́ kí èmi ríran.”
Co chcesz, abym ci uczynił? A on rzekł: Panie! abym przejrzał.
42 Jesu sì wí fún un pé, “Ríran; ìgbàgbọ́ rẹ mú ọ láradá.”
A Jezus mu rzekł: Przejrzyj, wiara twoja ciebie uzdrowiła.
43 Lójúkan náà ó sì ríran, ó sì ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, ó sì ń yin Ọlọ́run lógo àti gbogbo ènìyàn nígbà tí wọ́n rí i, wọ́n fi ìyìn fún Ọlọ́run.
I zarazem przejrzał, i szedł za nim, wielbiąc Boga. Co wszystek lud widząc, dał chwałę Bogu.