< Luke 18 >

1 Ó sì pa òwe kan fún wọn láti fi yé wọn pe, ó yẹ kí a máa gbàdúrà nígbà gbogbo, kí a má sì ṣàárẹ̀.
[Jesus] told [his disciples] a parable to teach them that they always ought to pray confidently and not be discouraged [if God does not immediately answer their prayers].
2 Wí pé, “Onídàájọ́ kan wà ní ìlú kan, tí kò bẹ̀rù Ọlọ́run, tí kò sì ṣe ojúsàájú ènìyàn.
He said, “In a certain city there was a judge who did not revere God, and did not care about people, either.
3 Opó kan sì wà ní ìlú náà, ó sì ń tọ̀ ọ́ wá, wí pé, ‘Gbẹ̀san mi lára ọ̀tá mi!’
There was a widow in that city who kept coming to him, saying, ‘Please decide what is just [in the dispute between me and] the man who is opposing me [in court!’]
4 “Lákọ̀ọ́kọ́ kò dá a lóhùn, ṣùgbọ́n níkẹyìn ó wí nínú ara rẹ̀ pé, ‘Bí èmi kò tilẹ̀ bẹ̀rù Ọlọ́run, tí èmi kò sì ṣe ojúsàájú ènìyàn,
For a long time the judge refused [to help her]. But later he thought to himself, ‘I do not revere God and I do not care about people,
5 Ṣùgbọ́n nítorí tí opó yìí ń yọ mí lẹ́nu, èmi ó gbẹ̀san rẹ̀, kí ó má ba à fi wíwá rẹ̀ nígbàkígbà dá mi lágara.’”
but this widow keeps bothering me! So I will make sure that she is treated justly. [If I do not do that], she will exhaust me by continually coming to me!’”
6 Olúwa sì wí pé, “Ẹ gbọ́ bí aláìṣòótọ́ onídàájọ́ ti wí!
Then the Lord [Jesus] said, “[Even though] the judge was not a righteous man, think carefully about what he said!
7 Ọlọ́run kì yóò ha sì gbẹ̀san àwọn àyànfẹ́ rẹ̀, tí ń fi ọ̀sán àti òru kígbe pè é, tí ó sì mú sùúrù fún wọn?
[Similarly], (God will certainly show that [what you] have done has been right!/will God not show that [what you] have done has been right?) [RHQ] He will do this for you whom he has chosen. [He will do this for you] who pray earnestly to him night and day, asking him to [help you]. He may delay [helping you].
8 Mo wí fún yín, yóò gbẹ̀san wọn kánkán! Ṣùgbọ́n nígbà tí Ọmọ Ènìyàn bá dé yóò ha rí ìgbàgbọ́ ní ayé bí?”
But I tell you, [some day] he will show that what you did was right, and he will do it quickly. But when [I], the one who came from heaven, return to earth, (there may not be [many people who will still] be trusting [that I will vindicate them] (OR, who will still be trusting in me)./will there be [many people who will still] be trusting [that I will vindicate them] (OR, who will still be trusting in me)?) [RHQ]”
9 Ó sì pa òwe yìí fún àwọn kan tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé ara wọn pé, àwọn ni olódodo, tí wọ́n sì ń gan àwọn ẹlòmíràn,
[Jesus] also told a parable [to warn] people who mistakenly thought that they were doing things that made them acceptable to God. Besides, they also despised other people.
10 pé, “Àwọn ọkùnrin méjì gòkè lọ sí tẹmpili láti gbàdúrà, ọ̀kan jẹ́ Farisi, èkejì sì jẹ́ agbowó òde.
[He said this]: “Two men went up to the Temple [in Jerusalem] to pray. One was a Pharisee. The other was a tax collector.
11 Èyí Farisi dìde, ó sì ń gbàdúrà nínú ara rẹ̀ báyìí pé, ‘Ọlọ́run mo dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ, nítorí tí èmi kò rí bí àwọn ará ìyókù, àwọn alọ́nilọ́wọ́gbà, aláìṣòótọ́, panṣágà, tàbí bí agbowó òde yìí.
The Pharisee stood and prayed silently, ‘God, I thank you that I am not like other men. [Some] extort money [from others]; some treat others unjustly; some commit adultery. [I do not do such things. And I am certainly not] like this tax collector [who cheats people]!
12 Èmi ń gbààwẹ̀ lẹ́ẹ̀méjì ní ọ̀sẹ̀, mo ń san ìdámẹ́wàá ohun gbogbo tí mo ní.’
[Our law says that we(exc) should] (fast/abstain from food) [once a week], [but I do more than that. I] fast twice a week! I give [you] ten percent of all that I earn!’
13 “Ṣùgbọ́n agbowó òde dúró lókèèrè, kò tilẹ̀ jẹ́ gbé ojú rẹ̀ sókè ọ̀run, ṣùgbọ́n ó lu ara rẹ̀ ní oókan àyà, ó wí pé, ‘Ọlọ́run ṣàánú fún mi, èmi ẹlẹ́ṣẹ̀!’
But the tax collector stood far [from the other people in the Temple courtyard because he felt very unworthy]. He would not even look up toward heaven. Instead, he beat on his chest [to show that he was sorry for his sin]. He said, ‘God, I am a sinner; be merciful to me [and forgive me]!’”
14 “Mo wí fún yín, ọkùnrin yìí sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ̀ ní ìdáláre ju èkejì lọ: nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá gbé ara rẹ̀ ga, òun ni a ó rẹ̀ sílẹ̀; ẹni tí ó bá sì rẹ̀ ara rẹ̀ sílẹ̀ òun ni a ó gbéga.”
[Then Jesus said], “I tell you [(pl)] that as the tax collector went home, the record of his sins was erased {[God] erased the record of his sins}, not that of the Pharisee. [Remember this]: Those who exalt themselves will be humbled {[God] will humble all those who exalt themselves}, but those who humble themselves will be exalted {[he] will exalt those who humble themselves}.”
15 Wọ́n sì gbé àwọn ọmọ ọwọ́ tọ̀ ọ́ wá pẹ̀lú, kí ó lè gbé ọwọ́ lé wọn; ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ rí i, wọ́n ń bá wọn wí.
[One day when many people were coming to Jesus], they were also bringing small children. They wanted him to put his hands on [the children and bless them]. When the disciples saw that, they rebuked [those who were bringing those children].
16 Ṣùgbọ́n Jesu pè wọ́n sọ́dọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé, “Ẹ jẹ́ kí àwọn ọmọ kékeré wá sọ́dọ̀ mi, ẹ má sì ṣe dá wọn lẹ́kun, nítorí tí irú wọn ni ìjọba Ọlọ́run.
But Jesus called the children [to come to him]. He said to his disciples, “Let the children come to me! Do not stop them! It is people who are [humble and trusting] like they are who can experience God ruling [their lives].
17 Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ẹnikẹ́ni tí kò bá gbà ìjọba Ọlọ́run bí ọmọ kékeré, kì yóò wọ inú rẹ̀ bí ó ti wù kí ó rí.”
Note this: Those who do not [trust God and] allow him to direct [their lives], as children [do], will not enter the [MET] place where God rules.”
18 Ìjòyè kan sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, wí pé, “Olùkọ́ rere, kín ni èmi ó ṣe tí èmi ó fi jogún ìyè àìnípẹ̀kun?” (aiōnios g166)
A [Jewish] leader asked [Jesus], “Good teacher, what shall I do in order to have eternal life?” (aiōnios g166)
19 Jesu wí fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń pè mí ní ẹni rere? Ẹni rere kan kò sí bí kò ṣe ẹnìkan, èyí sì ni Ọlọ́run.
Jesus said to him, “Only God is good! No one [else] is good! (So you(sg) should consider carefully what [you are implying by] calling me good!/[Do you realize that you are implying that I am God by] calling me good?) [RHQ]
20 Ìwọ mọ̀ àwọn òfin: ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe panṣágà, ìwọ kò gbọdọ̀ pànìyàn, ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe jalè, ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe jẹ́rìí èké, bọ̀wọ̀ fún baba àti ìyá rẹ.’”
[But to answer your question], you [(sg)] know the commandments that [God gave Moses. He commanded such things as] ‘do not commit adultery, do not commit murder, do not steal, do not testify falsely [about what you have seen or heard], honor your father and mother.’”
21 Ó sì wí pé, “Gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni èmi ti pamọ́ láti ìgbà èwe mi wá.”
The man said, “I have obeyed all those [commandments] ever since I was young. [So] ([there must be something else I have not done./is that enough]?)”
22 Nígbà tí Jesu sì gbọ́ èyí, ó wí fún un pé, “Ohun kan ni ó kù fún ọ síbẹ̀: lọ ta ohun gbogbo tí o ní, kí o sì pín in fún àwọn tálákà, ìwọ ó sì ní ìṣúra ní ọ̀run: sì wá, kí o máa tọ̀ mí lẹ́yìn.”
When Jesus heard [him say] that, he replied to him, “There is one thing that you [(sg)] have not [done] yet. Sell all that you own. Then give [the money] to poor people. [The result will be that] you will have [spiritual] riches in heaven. Then come and be my disciple!”
23 Nígbà tí ó sì gbọ́ èyí, inú rẹ̀ bàjẹ́ gidigidi, nítorí tí ó ní ọrọ̀ púpọ̀.
The man became sad when he heard that, because he was very rich [and he did not want to give everything away].
24 Nígbà tí Jesu rí i pé inú rẹ̀ bàjẹ́ gidigidi, ó wí pé, “Yóò ti ṣòro tó fún àwọn tí ó ní ọrọ̀ láti wọ ìjọba Ọlọ́run!
Jesus looked at the man [as he left], and said, “It is very difficult for those who are wealthy [to decide] to let God rule [MET] their [lives].
25 Nítorí ó rọrùn fún ìbákasẹ láti gba ojú abẹ́rẹ́ wọlé jù fún ọlọ́rọ̀ láti wọ ìjọba Ọlọ́run lọ.”
[You would say] that it is impossible for a camel to go through the eye of a needle. It is [almost] as difficult [HYP] for rich people [to decide] to let God rule their [lives].”
26 Àwọn tí ó sì gbọ́ wí pé, “Ǹjẹ́ ta ni ó ha lè là?”
[The Jews thought that God favored rich people, so they thought that if God did not save rich people, he would not save others, either]. So [one of the disciples] who heard him say that replied, “If that is so, it seems that no one will be saved {[that God] will not save anyone} [RHQ]!”
27 Ó sì wí pé, “Ohun tí ó ṣòro lọ́dọ̀ ènìyàn kò ṣòro lọ́dọ̀ Ọlọ́run.”
But Jesus said, “It is impossible for people [to save themselves]. But [God can save them, because] God can do anything!”
28 Peteru sì wí pé, “Sá wò ó, àwa ti fi ilé wa sílẹ̀, a sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn!”
Then Peter said, “[You know that we(exc) have left] everything we had and have become your disciples [RHQ]. [So what about us?] (OR, [So will God accept/save us?]”)
29 Ó sì wí fún wọn pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, kò sí ẹni tí ó fi ilé, tàbí aya, tàbí ará, tàbí òbí, tàbí ọmọ sílẹ̀, nítorí ìjọba Ọlọ́run,
He said to them, “Keep this in mind: Those who have left [their] homes, [their] wives, [their] brothers, [their] parents, [their] children, [or any other family members], [to tell others] about how God wants to rule [MET] [people’s lives],
30 tí kì yóò gba ìlọ́po púpọ̀ sí i ní ayé yìí, àti ní ayé tí ń bọ̀ ìyè àìnípẹ̀kun.” (aiōn g165, aiōnios g166)
will receive in this life many times as much [as they left]. And in the future age they will (live eternally [with God]/ have eternal life).” (aiōn g165, aiōnios g166)
31 Nígbà náà ni ó pe àwọn méjìlá sọ́dọ̀ rẹ̀, ó sì wí fún wọn pé, “Sá wò ó, àwa ń gòkè lọ sí Jerusalẹmu, a ó sì mú ohun gbogbo ṣẹ, tí a ti kọ láti ọwọ́ àwọn wòlíì, nítorí Ọmọ Ènìyàn.
[Jesus] took the twelve [disciples] to a place by themselves and said to them, “Listen carefully! We [(inc)] are [now] going up to Jerusalem. [While we are there], everything that has been written by the prophets {that the prophets have written} about [me], the one who came from heaven, will be fulfilled {will occur}.
32 Nítorí tí a ó fi lé àwọn aláìkọlà lọ́wọ́, a ó fi ṣe ẹlẹ́yà, a ó sì fi ṣe ẹ̀sín, a ó sì tutọ́ sí i lára.
I will be put into the hands of {[My enemies] will hand me over to} non-Jews. [The non-Jews] will make fun of me and mistreat me and spit on me.
33 Wọn ó sì nà án, wọn ó sì pa á, ní ọjọ́ kẹta yóò sì jíǹde.”
They will whip me, and [then] they will kill me. But on the third day [after that] I will become alive again.”
34 Ọ̀kan nínú nǹkan wọ̀nyí kò sì yé wọn, ọ̀rọ̀ yìí sì pamọ́ fún wọn, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì mọ ohun tí a wí.
But [the disciples] did not understand any of those things that [he said]. They were prevented {[Something] prevented them} from understanding the meaning of what [he] was telling [them].
35 Bí ó ti súnmọ́ Jeriko, afọ́jú kan jókòó lẹ́bàá ọ̀nà ó ń ṣagbe.
As [Jesus and his disciples] came near to Jericho [city], a blind man was sitting beside the road. [He was] begging [for money].
36 Nígbà tí ó gbọ́ tí ọ̀pọ̀ ń kọjá lọ, ó béèrè pé, kín ni ìtumọ̀ èyí.
When he heard the crowd [of people] passing by, he asked someone, “What is happening?”
37 Wọ́n sì wí fún un pé, “Jesu ti Nasareti ni ó ń kọjá lọ.”
They told him, “Jesus, [the man] from Nazareth [town], is passing by.”
38 Ó sì kígbe pé, “Jesu, ìwọ ọmọ Dafidi, ṣàánú fún mi!”
He shouted, “Jesus, [you who are] descended from [King] David, [the Messiah], pity me!”
39 Àwọn tí ń lọ níwájú bá a wí, pé, kí ó pa ẹnu rẹ̀ mọ́, ṣùgbọ́n òun sì kígbe sókè sí í pé, “Ìwọ Ọmọ Dafidi, ṣàánú fún mi!”
Those who were [walking] at the front [of the crowd] scolded the man [and] told him to be quiet. But he shouted more loudly, “You who are descended from [King] David, [the Messiah], pity me!”
40 Jesu sì dúró, ó ní, kí á mú un tọ òun wá nígbà tí ó sì súnmọ́ ọn, ó bi í
Jesus stopped and told [people] to bring the man to him. When [the blind man] came near, Jesus asked him,
41 wí pé, “Kí ni ìwọ ń fẹ́ kí èmi ṣe fún ọ?” Ó sì wí pé, “Olúwa jẹ́ kí èmi ríran.”
“What do you [(sg)] want me to do for you?” He replied, “Lord, enable me to see [again]!”
42 Jesu sì wí fún un pé, “Ríran; ìgbàgbọ́ rẹ mú ọ láradá.”
Jesus said to him, “[Then] see! Because you have trusted [PRS] [in me], [I] have healed you!”
43 Lójúkan náà ó sì ríran, ó sì ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, ó sì ń yin Ọlọ́run lógo àti gbogbo ènìyàn nígbà tí wọ́n rí i, wọ́n fi ìyìn fún Ọlọ́run.
Immediately he was able to see! And he went with [Jesus], praising God. And when all the people who were [going with Jesus] saw it, they also praised God.

< Luke 18 >