< Luke 17 >
1 Ó sì wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Kò le ṣe kí ohun ìkọ̀sẹ̀ máa wa, ṣùgbọ́n ègbé ni fún ẹni tí ó ti ipasẹ̀ rẹ̀ dé.
Atunci le-a spus discipolilor: Este imposibil să nu vină poticnirile; dar vai aceluia prin care vin!
2 Ìbá sàn fún un kí a so ọlọ mọ́ ọn ní ọrùn, kí a sì gbé e jù sínú Òkun, ju kí ó mú ọ̀kan nínú àwọn kékeré wọ̀nyí kọsẹ̀.
Ar fi mai bine pentru el dacă i s-ar lega în jurul gâtului o piatră de moară și să fie aruncat în mare, decât să poticnească pe unul dintre acești micuți.
3 Ẹ máa kíyèsára yín. “Bí arákùnrin rẹ bá ṣẹ̀, bá a wí; bí ó bá sì ronúpìwàdà, dáríjì ín.
Luați seama la voi înșivă și dacă fratele tău încalcă legea împotriva ta, mustră-l; și dacă se pocăiește, iartă-l.
4 Bí ó bá sì ṣẹ̀ ọ́ ní igba méje ní òòjọ́, tí ó padà tọ̀ ọ́ wá ní ìgbà méje ní òòjọ́ pé, ‘Mo ronúpìwàdà,’ dáríjì ín.”
Și dacă încalcă legea împotriva ta de șapte ori într-o zi și de șapte ori într-o zi se întoarce la tine, spunând: Mă pocăiesc; iartă-l.
5 Àwọn aposteli sì wí fún Olúwa pé, “Bù sí ìgbàgbọ́ wa.”
Și apostolii au spus Domnului: Mărește-ne credința.
6 Olúwa sì wí pé, “Bí ẹ̀yin bá ní ìgbàgbọ́ bí hóró irúgbìn musitadi, ẹ̀yin yóò lè wí fún igi sikamine yìí pé, ‘Di fi fà á tu, kí a sì gbìn ọ́ sínú Òkun,’ yóò sì gbọ́ tiyín.
Iar Domnul a spus: Dacă ați avea credință cât un grăunte de muștar, ați spune acestui sicomor: Dezrădăcinează-te și sădește-te în mare; și ar asculta de voi.
7 “Ṣùgbọ́n ta ni nínú yín, tí ó ní ọmọ ọ̀dọ̀, tí ó ń tulẹ̀, tàbí tí ó ń bọ́ ẹran, tí yóò wí fún un lójúkan náà tí ó bá ti oko dé pé, ‘Lọ í jókòó láti jẹun’?
Dar care dintre voi, având un rob arând sau păstorind vitele, îi va spune îndată după ce vine din câmp: Mergi și șezi la masă?
8 Tí kì yóò kúkú wí fún un pé, ‘Pèsè ohun tí èmi yóò jẹ, sì di àmùrè, kí ìwọ kí ó máa ṣe ìránṣẹ́ fún mi, títí èmi ó fi jẹ kí èmi ó sì mu tán; lẹ́yìn náà ni ìwọ ó sì jẹ, tí ìwọ ó sì mu’?
Și nu îi va spune mai degrabă: Pregătește-mi ceva să mănânc și încinge-te și servește-mi, până voi mânca și voi bea; și după acestea, vei mânca și vei bea tu?
9 Òun ó ha máa dá ọpẹ́ lọ́wọ́ ọmọ ọ̀dọ̀ náà, nítorí ó ṣe ohun tí a pàṣẹ fún un bí? Èmi kò rò bẹ́ẹ̀.
Îi mulțumește acelui rob, pentru că a făcut ce îi fusese poruncit? Consider că nu.
10 Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin pẹ̀lú, nígbà tí ẹ bá ti ṣe ohun gbogbo tí a pàṣẹ fún yín tán, ẹ wí pé, ‘Aláìlérè ọmọ ọ̀dọ̀ ni wá: èyí tí í ṣe iṣẹ́ wa láti ṣe, ní àwa ti ṣe.’”
Tot așa și voi, când veți fi făcut toate cele poruncite vouă, să spuneți: Suntem robi nefolositori, am făcut ce era datoria noastră să facem.
11 Ó sì ṣe, bí ó ti ń lọ sí Jerusalẹmu, ó kọjá láàrín Samaria Galili.
Și s-a întâmplat, pe când mergea el la Ierusalim, că a trecut prin mijlocul Samariei și Galileii.
12 Bí ó sì ti ń wọ inú ìletò kan lọ, àwọn ọkùnrin adẹ́tẹ̀ mẹ́wàá pàdé rẹ̀, wọ́n dúró ní òkèrè,
Și când a intrat într-un anumit sat, l-au întâlnit zece bărbați leproși, care stăteau departe în picioare;
13 wọ́n sì kígbe sókè wí pé, “Jesu, Olùkọ́, ṣàánú fún wa.”
Și ei și-au ridicat vocea, spunând: Isuse, Stăpâne, ai milă de noi.
14 Nígbà tí ó rí wọn, ó wí fún wọn pé, “Ẹ lọ í fi ara yín hàn fún àwọn àlùfáà.” Ó sì ṣe, bí wọ́n ti ń lọ, wọ́n sì di mímọ́.
Și când i-a văzut, le-a spus: Duceți-vă, arătați-vă preoților. Și s-a întâmplat că, pe când mergeau ei, au fost curățiți.
15 Nígbà tí ọ̀kan nínú wọn rí i pé a mú òun láradá ó padà, ó sì fi ohùn rara yin Ọlọ́run lógo.
Și unul dintre ei, când a văzut că a fost vindecat, s-a întors și cu voce tare glorifica pe Dumnezeu.
16 Ó sì wólẹ̀ lẹ́bàá ẹsẹ̀ rẹ̀, ó ń dúpẹ́ ní ọwọ́ rẹ̀: ará Samaria ni òun í ṣe.
Și a căzut cu fața la pământ la picioarele lui, dându-i mulțumiri; și el era samaritean.
17 Jesu sì dáhùn wí pé, “Àwọn mẹ́wàá kí a sọ di mímọ́? Àwọn mẹ́sàn-án ìyókù ha dà?
Iar Isus, răspunzând, a zis: Nu au fost zece curățiți? Dar unde sunt cei nouă?
18 A kò rí ẹnìkan tí ó padà wá fi ògo fún Ọlọ́run, bí kò ṣe àlejò yìí?”
Nu s-a găsit cine să se întoarcă și să dea glorie lui Dumnezeu decât acest străin?
19 Ó sì wí fún un pé, “Dìde, kí o sì máa lọ, ìgbàgbọ́ rẹ mú ọ láradá.”
Și i-a spus: Scoală-te, du-te; credința ta te-a făcut sănătos.
20 Nígbà tí àwọn Farisi bi í pé, nígbà wo ni ìjọba Ọlọ́run yóò dé, ó dá wọn lóhùn pé, “Ìjọba Ọlọ́run kì í wá pẹ̀lú àmì.
Și fiind întrebat de farisei, când are să vină împărăția lui Dumnezeu, le-a răspuns și a zis: Împărăția lui Dumnezeu nu vine la vedere;
21 Bẹ́ẹ̀ ni wọn kì yóò wí pé, ‘Kíyèsi i níhìn-ín!’ tàbí ‘Kíyèsi i lọ́hùn ún ni!’ sá à wò ó, ìjọba Ọlọ́run ń bẹ nínú yín.”
Nici nu vor spune: Iat-o aici! Sau: Iat-o acolo! Căci, iată, împărăția lui Dumnezeu este înăuntrul vostru.
22 Ó sì wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Ọjọ́ ń bọ̀, nígbà tí ẹ̀yin yóò fẹ́ láti rí ọ̀kan nínú ọjọ́ Ọmọ Ènìyàn, ẹ̀yin kì yóò sì rí i.
Și le-a spus discipolilor: Vor veni zilele când veți dori să vedeți una dintre zilele Fiului omului și nu veți vedea.
23 Wọ́n sì wí fún yín pé, ‘Wò ó níhìn-ín!’ tàbí ‘Wò ó lọ́hùn ún!’ Ẹ máa lọ, ẹ má ṣe tẹ̀lé wọn.
Și vă vor spune: Iată, aici; sau: Iată, acolo. Nu vă duceți, nici nu îi urmați.
24 Nítorí gẹ́gẹ́ bí mọ̀nàmọ́ná ti í kọ ní apá kan lábẹ́ ọ̀run, tí sì í mọ́lẹ̀ ní apá kejì lábẹ́ ọ̀run, bẹ́ẹ̀ ni Ọmọ Ènìyàn yóò sì rí ní ọjọ́ rẹ̀.
Pentru că așa ca fulgerul, care fulgerând dintr-o parte de sub cer, strălucește până în cealaltă parte de sub cer; așa va fi și Fiul omului în ziua lui.
25 Ṣùgbọ́n kò lè ṣàìmá kọ́ jìyà ohun púpọ̀, kí a sì kọ̀ ọ́ lọ́dọ̀ ìran yìí.
Dar mai întâi el trebuie să sufere multe și să fie respins de această generație.
26 “Bí ó ti rí ní ọjọ́ Noa, bẹ́ẹ̀ ni yóò rí ní ọjọ́ Ọmọ Ènìyàn.
Și cum a fost în zilele lui Noe, tot așa va fi și în zilele Fiului omului.
27 Wọ́n ń jẹ, wọ́n ń mu, wọ́n ń gbéyàwó, wọ́n sì ń fa ìyàwó fún ni, títí ó fi di ọjọ́ ti Noa wọ inú ọkọ̀ lọ, kíkún omi sì dé, ó sì run gbogbo wọn.
Mâncau, beau, se însurau, se măritau, până în ziua când Noe a intrat în arcă și potopul a venit și i-a nimicit pe toți.
28 “Bí ó sì ti rí ní ọjọ́ Lọti; wọ́n ń jẹ, wọ́n ń mu, wọ́n ń rà, wọ́n ń tà, wọ́n ń gbìn, wọ́n ń kọ́lé,
Și la fel cum a fost în zilele lui Lot, mâncau, beau, cumpărau, vindeau, plantau, zideau;
29 ṣùgbọ́n ní ọjọ́ náà tí Lọti jáde kúrò ní Sodomu, òjò iná àti sulfuru rọ̀ láti ọ̀run wá, ó sì run gbogbo wọn.
Dar în acea zi când Lot a ieșit din Sodoma, a plouat foc și pucioasă din cer și i-a nimicit pe toți.
30 “Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni yóò rí ní ọjọ́ náà tí Ọmọ Ènìyàn yóò farahàn.
Întocmai, astfel va fi în ziua când Fiul omului se revelează.
31 Ní ọjọ́ náà, ẹni tí ó bá wà lórí ilé, tí ẹrù rẹ̀ sì ń bẹ ní ilẹ̀, kí ó má ṣe sọ̀kalẹ̀ láti wá kó o; ẹni tí ó bá sì wà ní oko, kí ó má ṣe padà sẹ́yìn.
În acea zi, cel ce va fi pe acoperișul casei și bunurile lui în casă, să nu se coboare să le ia; și cel ce este pe câmp, la fel, să nu se întoarcă.
Amintiți-vă de soția lui Lot.
33 Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń wá àti gba ẹ̀mí rẹ̀ là yóò sọ ọ́ nù; ẹnikẹ́ni tí ó bá sì sọ ọ́ nù yóò gbà á là.
Oricine va căuta să își salveze viața, o va pierde; și oricine își va pierde viața, o va păstra.
34 Mo wí fún yín, ní òru ọjọ́ náà, ènìyàn méjì yóò wà lórí àkéte kan; a ó mú ọ̀kan, a ó sì fi èkejì sílẹ̀.
Vă spun: În acea noapte, vor fi doi într-un pat; unul va fi luat și celălalt va fi lăsat.
35 Ènìyàn méjì yóò sì máa lọ ọlọ pọ̀; a ó mú ọ̀kan, a ó sì fi èkejì sílẹ̀.”
Două vor măcina împreună; una va fi luată și cealaltă va fi lăsată.
Doi vor fi la câmp; unul va fi luat și celălalt va fi lăsat.
37 Wọ́n sì dá a lóhùn, wọ́n bi í pé, “Níbo, Olúwa?” Ó sì wí fún wọn pé, “Níbi tí òkú bá gbé wà, níbẹ̀ pẹ̀lú ni igún ìkójọpọ̀ sí.”
Iar ei au răspuns și i-au zis: Unde Doamne? Iar el le-a spus: Oriunde este trupul, acolo se vor aduna vulturii.