< Luke 17 >
1 Ó sì wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Kò le ṣe kí ohun ìkọ̀sẹ̀ máa wa, ṣùgbọ́n ègbé ni fún ẹni tí ó ti ipasẹ̀ rẹ̀ dé.
And Jhesu seide to hise disciplis, It is impossible that sclaundris come not; but wo to that man, bi whom thei comen.
2 Ìbá sàn fún un kí a so ọlọ mọ́ ọn ní ọrùn, kí a sì gbé e jù sínú Òkun, ju kí ó mú ọ̀kan nínú àwọn kékeré wọ̀nyí kọsẹ̀.
It is more profitable to him, if a mylne stoon be put aboute his necke, and he be cast in to the see, than that he sclaundre oon of these litle.
3 Ẹ máa kíyèsára yín. “Bí arákùnrin rẹ bá ṣẹ̀, bá a wí; bí ó bá sì ronúpìwàdà, dáríjì ín.
Take ye hede you silf; if thi brothir hath synned ayens thee, blame hym; and if he do penaunce, foryyue hym.
4 Bí ó bá sì ṣẹ̀ ọ́ ní igba méje ní òòjọ́, tí ó padà tọ̀ ọ́ wá ní ìgbà méje ní òòjọ́ pé, ‘Mo ronúpìwàdà,’ dáríjì ín.”
And if seuene sithis in the dai he do synne ayens thee, and seuene sithis in the dai he be conuertid to thee, and seie, It forthenkith me, foryyue thou hym.
5 Àwọn aposteli sì wí fún Olúwa pé, “Bù sí ìgbàgbọ́ wa.”
And the apostlis seiden to the Lord, Encrese to vs feith.
6 Olúwa sì wí pé, “Bí ẹ̀yin bá ní ìgbàgbọ́ bí hóró irúgbìn musitadi, ẹ̀yin yóò lè wí fún igi sikamine yìí pé, ‘Di fi fà á tu, kí a sì gbìn ọ́ sínú Òkun,’ yóò sì gbọ́ tiyín.
And the Lord seide, If ye han feith as the corn of seneuei, ye schulen seie to this more tre, Be thou drawun vp bi the rote, and be ouerplauntid in to the see, and it schal obeie to you.
7 “Ṣùgbọ́n ta ni nínú yín, tí ó ní ọmọ ọ̀dọ̀, tí ó ń tulẹ̀, tàbí tí ó ń bọ́ ẹran, tí yóò wí fún un lójúkan náà tí ó bá ti oko dé pé, ‘Lọ í jókòó láti jẹun’?
But who of you hath a seruaunt erynge, or lesewynge oxis, which seith to hym, whanne he turneth ayen fro the feeld, Anoon go, and sitte to mete;
8 Tí kì yóò kúkú wí fún un pé, ‘Pèsè ohun tí èmi yóò jẹ, sì di àmùrè, kí ìwọ kí ó máa ṣe ìránṣẹ́ fún mi, títí èmi ó fi jẹ kí èmi ó sì mu tán; lẹ́yìn náà ni ìwọ ó sì jẹ, tí ìwọ ó sì mu’?
and seith not to hym, Make redi, that Y soupe, and girde thee, and serue me, while Y ete and drynke, and aftir this thou schalt ete and drynke;
9 Òun ó ha máa dá ọpẹ́ lọ́wọ́ ọmọ ọ̀dọ̀ náà, nítorí ó ṣe ohun tí a pàṣẹ fún un bí? Èmi kò rò bẹ́ẹ̀.
whether he hath grace to that seruaunt, for he dide that that he comaundide hym?
10 Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin pẹ̀lú, nígbà tí ẹ bá ti ṣe ohun gbogbo tí a pàṣẹ fún yín tán, ẹ wí pé, ‘Aláìlérè ọmọ ọ̀dọ̀ ni wá: èyí tí í ṣe iṣẹ́ wa láti ṣe, ní àwa ti ṣe.’”
Nay, Y gesse. So ye, whanne ye han don alle thingis that ben comaundid to you, seie ye, We ben vnprofitable seruauntis, we han do that that we ouyten to do.
11 Ó sì ṣe, bí ó ti ń lọ sí Jerusalẹmu, ó kọjá láàrín Samaria Galili.
And it was do, the while Jhesus wente in to Jerusalem, he passide thorou the myddis of Samarie, and Galilee.
12 Bí ó sì ti ń wọ inú ìletò kan lọ, àwọn ọkùnrin adẹ́tẹ̀ mẹ́wàá pàdé rẹ̀, wọ́n dúró ní òkèrè,
And whanne he entride in to a castel, ten leprouse men camen ayens hym, whiche stoden afer,
13 wọ́n sì kígbe sókè wí pé, “Jesu, Olùkọ́, ṣàánú fún wa.”
and reiseden her voys, and seiden, Jhesu, comaundoure, haue merci on vs.
14 Nígbà tí ó rí wọn, ó wí fún wọn pé, “Ẹ lọ í fi ara yín hàn fún àwọn àlùfáà.” Ó sì ṣe, bí wọ́n ti ń lọ, wọ́n sì di mímọ́.
And as he say hem, he seide, Go ye, `schewe ye you to the prestis. And it was don, the while thei wenten, thei weren clensid.
15 Nígbà tí ọ̀kan nínú wọn rí i pé a mú òun láradá ó padà, ó sì fi ohùn rara yin Ọlọ́run lógo.
And oon of hem, as he saiy that he was clensid, wente ayen, magnifiynge God with grete vois.
16 Ó sì wólẹ̀ lẹ́bàá ẹsẹ̀ rẹ̀, ó ń dúpẹ́ ní ọwọ́ rẹ̀: ará Samaria ni òun í ṣe.
And he fel doun on the face bifore hise feet, and dide thankyngis; and this was a Samaritan.
17 Jesu sì dáhùn wí pé, “Àwọn mẹ́wàá kí a sọ di mímọ́? Àwọn mẹ́sàn-án ìyókù ha dà?
And Jhesus answerde, and seide, Whether ten ben not clensid, and where ben the nyne?
18 A kò rí ẹnìkan tí ó padà wá fi ògo fún Ọlọ́run, bí kò ṣe àlejò yìí?”
There is noon foundun, that turnede ayen, and yaf glorie to God, but this alien.
19 Ó sì wí fún un pé, “Dìde, kí o sì máa lọ, ìgbàgbọ́ rẹ mú ọ láradá.”
And he seide to hym, Rise vp, go thou; for thi feith hath maad thee saaf.
20 Nígbà tí àwọn Farisi bi í pé, nígbà wo ni ìjọba Ọlọ́run yóò dé, ó dá wọn lóhùn pé, “Ìjọba Ọlọ́run kì í wá pẹ̀lú àmì.
And he was axid of Farisees, whanne the rewme of God cometh. And he answerde to hem, and seide, The rewme of God cometh not with aspiyng,
21 Bẹ́ẹ̀ ni wọn kì yóò wí pé, ‘Kíyèsi i níhìn-ín!’ tàbí ‘Kíyèsi i lọ́hùn ún ni!’ sá à wò ó, ìjọba Ọlọ́run ń bẹ nínú yín.”
nether thei schulen seie, Lo! here, or lo there; for lo! the rewme of God is with ynne you.
22 Ó sì wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Ọjọ́ ń bọ̀, nígbà tí ẹ̀yin yóò fẹ́ láti rí ọ̀kan nínú ọjọ́ Ọmọ Ènìyàn, ẹ̀yin kì yóò sì rí i.
And he seide to hise disciplis, Daies schulen come, whanne ye schulen desire to se o dai of mannus sone, and ye schulen not se.
23 Wọ́n sì wí fún yín pé, ‘Wò ó níhìn-ín!’ tàbí ‘Wò ó lọ́hùn ún!’ Ẹ máa lọ, ẹ má ṣe tẹ̀lé wọn.
And thei schulen seie to you, Lo! here, and lo there. Nyle ye go, nether sue ye;
24 Nítorí gẹ́gẹ́ bí mọ̀nàmọ́ná ti í kọ ní apá kan lábẹ́ ọ̀run, tí sì í mọ́lẹ̀ ní apá kejì lábẹ́ ọ̀run, bẹ́ẹ̀ ni Ọmọ Ènìyàn yóò sì rí ní ọjọ́ rẹ̀.
for as leyt schynynge from vndur heuene schyneth in to tho thingis that ben vndur heuene, so schal mannus sone be in his dai.
25 Ṣùgbọ́n kò lè ṣàìmá kọ́ jìyà ohun púpọ̀, kí a sì kọ̀ ọ́ lọ́dọ̀ ìran yìí.
But first it bihoueth hym to suffre many thingis, and to be repreued of this generacioun.
26 “Bí ó ti rí ní ọjọ́ Noa, bẹ́ẹ̀ ni yóò rí ní ọjọ́ Ọmọ Ènìyàn.
And as it was doon in the daies of Noe, so it schal be in the daies of mannys sone.
27 Wọ́n ń jẹ, wọ́n ń mu, wọ́n ń gbéyàwó, wọ́n sì ń fa ìyàwó fún ni, títí ó fi di ọjọ́ ti Noa wọ inú ọkọ̀ lọ, kíkún omi sì dé, ó sì run gbogbo wọn.
Thei eeten and drunkun, weddiden wyues, and weren youun to weddyngis, til in to the dai in the whych Noe entride in to the schip; and the greet flood cam, and loste alle.
28 “Bí ó sì ti rí ní ọjọ́ Lọti; wọ́n ń jẹ, wọ́n ń mu, wọ́n ń rà, wọ́n ń tà, wọ́n ń gbìn, wọ́n ń kọ́lé,
Also as it was don in the daies of Loth, thei eeten and drunkun, bouyten and seelden, plauntiden and bildiden; but the dai that Loth wente out of Sodome,
29 ṣùgbọ́n ní ọjọ́ náà tí Lọti jáde kúrò ní Sodomu, òjò iná àti sulfuru rọ̀ láti ọ̀run wá, ó sì run gbogbo wọn.
the Lord reynede fier and brymstoon fro heuene, and loste alle.
30 “Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni yóò rí ní ọjọ́ náà tí Ọmọ Ènìyàn yóò farahàn.
Lijk this thing it schal be, in what dai mannys sone schal be schewid.
31 Ní ọjọ́ náà, ẹni tí ó bá wà lórí ilé, tí ẹrù rẹ̀ sì ń bẹ ní ilẹ̀, kí ó má ṣe sọ̀kalẹ̀ láti wá kó o; ẹni tí ó bá sì wà ní oko, kí ó má ṣe padà sẹ́yìn.
In that our he that is in the roof, and his vessels in the hous, come he not doun to take hem awei; and he that schal be in the feeld, also turne not ayen bihynde.
Be ye myndeful of the wijf of Loth.
33 Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń wá àti gba ẹ̀mí rẹ̀ là yóò sọ ọ́ nù; ẹnikẹ́ni tí ó bá sì sọ ọ́ nù yóò gbà á là.
Who euer seketh to make his lijf saaf, schal leese it; and who euer leesith it, schal quykene it.
34 Mo wí fún yín, ní òru ọjọ́ náà, ènìyàn méjì yóò wà lórí àkéte kan; a ó mú ọ̀kan, a ó sì fi èkejì sílẹ̀.
But Y seie to you, in that nyyt twei schulen be in o bed, oon schal be takun, and the tothir forsakun;
35 Ènìyàn méjì yóò sì máa lọ ọlọ pọ̀; a ó mú ọ̀kan, a ó sì fi èkejì sílẹ̀.”
twei wymmen schulen be gryndynge togidir, `the toon schal be takun, and `the tother forsakun; twei in a feeld, `the toon schal be takun, and `the tother left.
Thei answeren, and seien to hym, Where, Lord?
37 Wọ́n sì dá a lóhùn, wọ́n bi í pé, “Níbo, Olúwa?” Ó sì wí fún wọn pé, “Níbi tí òkú bá gbé wà, níbẹ̀ pẹ̀lú ni igún ìkójọpọ̀ sí.”
Which seide to hym, Where euer the bodi schal be, thidur schulen be gaderid togidere also the eglis.