< Luke 14 >

1 Nígbà tí ó wọ ilé ọ̀kan nínú àwọn olórí Farisi lọ ní ọjọ́ ìsinmi láti jẹun, wọ́n sì ń ṣọ́ ọ.
I stało się, gdy wszedł Jezus w dom niektórego przedniejszego Faryzeusza w sabat, aby jadł chleb, że go oni podstrzegali.
2 Sì kíyèsi i, ọkùnrin kan tí ó ní ara wíwú níwájú rẹ̀.
A oto człowiek niektóry opuchły był przed nim.
3 Jesu sì dáhùn ó wí fún àwọn amòfin àti àwọn Farisi pé, “Ǹjẹ́ ó tọ́ láti mú ni láradá ní ọjọ́ ìsinmi, tàbí kò tọ́?”
A odpowiadając Jezus, rzekł do zakonników, i do Faryzeuszów, mówiąc: Godzili się w sabat uzdrawiać?
4 Wọ́n sì dákẹ́. Ó sì mú un, ó mú un láradá, ó sì jẹ́ kí ó lọ.
A oni milczeli. Tedy on ująwszy go, uzdrowił i odprawił.
5 Ó sì dáhùn ó sì wí fún wọn pé, “Ta ni nínú yín tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tàbí màlúù rẹ̀ yóò bọ́ sínú ihò, tí kì yóò sì fà á sókè lójúkan náà ní ọjọ́ ìsinmi?”
A odpowiadając rzekł do nich: Któregoż z was osieł albo wół wpadnie w studnię, a nie wnet go wyciągnie w dzień sabatu?
6 Wọn kò sì lè dá a lóhùn mọ́ sí nǹkan wọ̀nyí.
I nie mogli mu na to odpowiedzieć.
7 Ó sì pa òwe kan fún àwọn tí ó pè é wá jẹun, nígbà tí ó ṣàkíyèsí bí wọ́n ti ń yan ipò ọlá; ó sì wí fún wọn pé,
Powiedział też i wezwanym podobieństwo, (bacząc, jako przedniejsze miejsca obierali, ) mówiąc do nich:
8 “Nígbà tí ẹnìkan bá pè ọ́ wá sí ibi ìyàwó, má ṣe jókòó ní ipò ọlá; kí ó má ba à jẹ́ pé, a ó pe ẹni tí ó lọ́lá jù ọ́ lọ.
Gdybyś był od kogo wezwany na wesele, nie siadajże na przedniejszem miejscu, by snać zacniejszy nad cię nie był wezwany od niego;
9 Nígbà tí ẹni tí ó pè ọ́ bá dé, a sì wí fún ọ pé, ‘Fún ọkùnrin yìí ní ààyè!’ Ìwọ á sì wá fi ìtìjú mú ipò ẹ̀yìn.
A przyszedłszy ten, który ciebie i onego wezwał, rzekłby tobie: Daj temu miejsce: a tedy byś ze wstydem począł siedzieć na pośledniem miejscu.
10 Ṣùgbọ́n nígbà tí a bá pè ọ́, lọ kí o sì jókòó ní ipò ẹ̀yìn; nígbà tí ẹni tí ó pè ọ́ bá dé, kí ó lè wí fún ọ pé, ‘Ọ̀rẹ́, bọ́ sókè!’ Nígbà náà ni ìwọ ó ní ìyìn lójú àwọn tí ó bá ọ jókòó ti oúnjẹ.
Ale gdybyś był wezwany, szedłszy, usiądź na pośledniem miejscu; a gdyby przyszedł ten, który cię wezwał, rzekłby tobie: Przyjacielu! posiądź się wyżej; tedy będziesz miał cześć przed spółsiedzącymi z tobą.
11 Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá gbé ara rẹ̀ ga, ni a ó rẹ̀ sílẹ̀; ẹnikẹ́ni tí ó bá sì rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀, ni a ó sì gbéga.”
Bo wszelki, kto się wywyższa, poniżony będzie, a kto się poniża, wywyższony będzie.
12 Nígbà náà ni ó sì wí fún alásè tí ó pè é pé, “Nígbà tí ìwọ bá ṣe àsè má ṣe pe àwọn arákùnrin rẹ tàbí àwọn ìbátan rẹ, tàbí àwọn ọlọ́rọ̀ aládùúgbò rẹ̀; nítorí kí wọn má ṣe pè ọ́ padà láti san ẹ̀san padà.
Mówił też i onemu, który go był wezwał: Gdy sprawujesz obiad albo wieczerzę, nie wzywajże przyjaciół twoich, ani braci twoich, ani krewnych twoich, ani sąsiadów bogatych, żeby cię snać i oni zasię nie wezwali, a stałaby ci się nagroda.
13 Ṣùgbọ́n nígbà tí ìwọ bá ṣe àsè, pe àwọn tálákà, àwọn alábùkún ara, àwọn amúnkùn ún, àti àwọn afọ́jú:
Ale gdy sprawujesz ucztę, wezwijże ubogich, ułomnych, chromych i ślepych,
14 Ìwọ ó sì jẹ́ alábùkún fún; nítorí wọn kò ní ohun tí wọn ó fi san án fún ọ, ṣùgbọ́n a ó san án fún ọ ní àjíǹde, àwọn olóòtítọ́.”
A będziesz błogosławionym; bo nie mają tobie czem nagrodzić, ale ci będzie nagrodzono przy zmartwychwstaniu sprawiedliwych.
15 Nígbà tí ọ̀kan nínú àwọn tí wọ́n jọ jókòó gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, ó wí fún Jesu pé, “Alábùkún ni fún ẹni tí yóò jẹ oúnjẹ àsè ní ìjọba Ọlọ́run!”
A usłyszawszy to niektóry z spółsiedzących, rzekł mu: Błogosławiony, który je chleb w królestwie Bożem.
16 Jesu dá a lóhùn pé, “Ọkùnrin kan ṣe àsè alẹ́ ńlá, ó sì pe ènìyàn púpọ̀.
A on mu rzekł: Człowiek niektóry sprawił wieczerzę wielką i zaprosił wielu;
17 Ó sì rán ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ ní wákàtí àsè alẹ́ náà láti sọ fún àwọn tí a ti pè pé, ‘Ẹ wá; nítorí ohun gbogbo ṣetán!’
I posłał sługę swego w godzinę wieczerzy, żeby rzekł zaproszonym: Pójdźcie! bo już wszystko gotowe.
18 “Gbogbo wọn sì bẹ̀rẹ̀ sí ṣe àwáwí ohun kan. ‘Èkínní wí fún un pé, mo ra ilẹ̀ kan, mo sì fẹ́ lọ wò ó wò, mo bẹ̀ ọ́ ṣe gáfárà fún mi.’
I poczęli się wszyscy jednostajnie wymawiać. Pierwszy mu rzekł: Kupiłem wieś, i muszę iść, a oglądać ją, proszę cię, miej mię za wymówionego.
19 “Èkejì sì wí pé, ‘Mo ra àjàgà màlúù márùn-ún, mo sì ń lọ wò wọ́n wò: mo bẹ̀ ọ́ ṣe gáfárà fún mi.’
A drugi rzekł: Kupiłem pięć jarzm wołów, i idę, abym ich doświadczył: proszę cię, miej mię za wymówionego.
20 “Ẹ̀kẹta sì wí pé, ‘Mo ṣẹ̀ṣẹ̀ gbéyàwó, nítorí náà ni èmi kò fi lè wá.’
A drugi rzekł: Żonęm pojął, a dlatego przyjść nie mogę.
21 “Ọmọ ọ̀dọ̀ náà sì padà dé, ó sọ nǹkan wọ̀nyí fún olúwa rẹ̀. Nígbà náà ni baálé ilé bínú, ó wí fún ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ pé, ‘Jáde lọ sí ìgboro, àti sí òpópó ọ̀nà, kí o sì mú àwọn tálákà, àti àwọn amúnkùn ún, àti àwọn arọ, àti àwọn afọ́jú wá sí ìhín yìí.’
A wróciwszy się on sługa, oznajmił to panu swemu. Tedy się gospodarz rozgniewawszy, rzekł słudze swemu: Wynijdź prędko na ulice i na drogi miejskie, a ubogie i ułomne i chrome i ślepe wprowadź tu.
22 “Ọmọ ọ̀dọ̀ náà sì wí pé, ‘Olúwa a ti ṣe bí o ti pàṣẹ, ààyè sì ń bẹ síbẹ̀.’
I rzekł sługa: Panie! stało się, jakoś rozkazał, a jeszcze miejsce jest.
23 “Olúwa náà sì wí fún ọmọ ọ̀dọ̀ náà pé, ‘Jáde lọ sí òpópó, àti sí ọ̀nà ọgbà, kí o sì rọ̀ wọ́n láti wọlé wá, kí ilé mi lè kún.
I rzekł Pan do sługi: Wynijdź na drogi i między opłotki, a przymuś wnijść, aby był napełniony dom mój.
24 Nítorí mo wí fún yín, ẹnikẹ́ni nínú àwọn ènìyàn wọ̀nyí tí a ti pè, kì yóò tọ́wò nínú àsè ńlá mi!’”
Albowiem powiadam wam, że żaden z onych mężów, którzy byli zaproszeni, nie ukusi wieczerzy mojej.
25 Àwọn ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn ń bá a lọ; ó sì yípadà, ó sì wí fún wọn pé,
I szedł z nim wielki lud; a obróciwszy się, rzekł do nich:
26 “Bí ẹnìkan bá tọ̀ mí wá, tí kò sì kórìíra baba àti ìyá, àti aya, àti ọmọ, àti arákùnrin, àti arábìnrin, àní àti ọkàn ara rẹ̀ pẹ̀lú, kò lè ṣe ọmọ-ẹ̀yìn mi.
Jeźli kto idzie do mnie, a nie ma w nienawiści ojca swego, i matki, i żony, i dzieci, i braci, i sióstr, nawet i duszy swojej, nie może być uczniem moim.
27 Ẹnikẹ́ni tí kò bá ru àgbélébùú rẹ̀, kí ó sì máa tọ̀ mí lẹ́yìn, kò lè ṣe ọmọ-ẹ̀yìn mi.
A ktokolwiek nie niesie krzyża swego, a idzie za mną, nie może być uczniem moim.
28 “Nítorí ta ni nínú yín tí ń pète láti kọ́ ilé ìṣọ́, tí kì yóò kọ́kọ́ jókòó kí ó ṣírò iye owó rẹ̀, bí òun ní tó tí yóò fi parí rẹ̀.
Bo któż z was jest, chcąc zbudować wieżę, aby pierwej usiadłszy, nie obrachował nakładu, mali to, czemby jej dokończył?
29 Kí ó má ba à jẹ́ pé nígbà tí ó bá fi ìpìlẹ̀ ilé sọlẹ̀ tan, tí kò lè parí rẹ̀ mọ́, gbogbo àwọn tí ó rí i a bẹ̀rẹ̀ sí í fi í ṣe ẹlẹ́yà.
Aby snać, gdyby założył fundament, a dokończyć nie mógł, wszyscy którzy by to widzieli, nie poczęli się naśmiewać z niego,
30 Wí pé, ‘Ọkùnrin yìí bẹ̀rẹ̀ sí kọ́ ilé, kò sì lè parí rẹ̀.’
Mówiąc: Ten człowiek począł budować, a nie mógł dokończyć.
31 “Tàbí ọba wo ni ó ń lọ bá ọba mìíràn jà, tí kì yóò kọ́kọ́ jókòó, kí ó sì gbèrò bí yóò lè fi ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá pàdé ẹni tí ń mú ogún ẹgbẹ̀rún bọ̀ wá ko òun lójú?
Albo który król jadąc na wojnę, potykać się z drugim królem, pierwej usiadłszy, nie radzi się, mógłliby się w dziesięć tysięcy spotkać z onym, który we dwadzieścia tysięcy jedzie przeciwko niemu?
32 Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, nígbà tí onítọ̀hún bá sì wà ní òkèrè, òun a rán ikọ̀ sí i, a sì bẹ̀rẹ̀ àdéhùn àlàáfíà.
A jeźli nie, gdy on jeszcze jest daleko od niego, posły wyprawiwszy do niego, prosi o to, co należy do pokoju.
33 Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni, ẹnikẹ́ni tí ó wù kí ó ṣe nínú yín, tí kò kọ ohun gbogbo tí ó ní sílẹ̀, kò lè ṣe ọmọ-ẹ̀yìn mi.
Takżeć i każdy z was, kto by się nie wyrzekł wszystkich majętności swoich, nie może być uczniem moim.
34 “Iyọ̀ dára: ṣùgbọ́n bí iyọ̀ bá di òbu, kín ni a ó fi mú un dùn?
Dobrać jest sól; lecz jeźli sól zwietrzeje, czemże ją naprawią?
35 Kò yẹ fún ilẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò yẹ fún ààtàn; bí kò ṣe pé kí a kó o dànù. “Ẹni tí ó bá ní etí láti fi gbọ́ kí ó gbọ́.”
Nie przygodzi się ani do ziemi ani do gnoju, ale ją precz wyrzucają. Kto ma uszy ku słuchaniu, niechaj słucha.

< Luke 14 >