< Luke 14 >

1 Nígbà tí ó wọ ilé ọ̀kan nínú àwọn olórí Farisi lọ ní ọjọ́ ìsinmi láti jẹun, wọ́n sì ń ṣọ́ ọ.
Pewnego razu, w święty dzień szabatu, Jezus gościł w domu jednego z przywódców faryzeuszy. Obecni tam goście śledzili każdy Jego ruch.
2 Sì kíyèsi i, ọkùnrin kan tí ó ní ara wíwú níwájú rẹ̀.
Wtedy stanął przed Nim człowiek cierpiący na wodną puchlinę.
3 Jesu sì dáhùn ó wí fún àwọn amòfin àti àwọn Farisi pé, “Ǹjẹ́ ó tọ́ láti mú ni láradá ní ọjọ́ ìsinmi, tàbí kò tọ́?”
Jezus zapytał więc zebranych tam faryzeuszy i przywódców religijnych: —Czy Prawo Mojżesza zezwala na uzdrowienie kogoś w szabat, czy nie?
4 Wọ́n sì dákẹ́. Ó sì mú un, ó mú un láradá, ó sì jẹ́ kí ó lọ.
Oni jednak nie opowiedzieli ani słowem. Wtedy Jezus wziął chorego za rękę, uzdrowił go i odesłał do domu.
5 Ó sì dáhùn ó sì wí fún wọn pé, “Ta ni nínú yín tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tàbí màlúù rẹ̀ yóò bọ́ sínú ihò, tí kì yóò sì fà á sókè lójúkan náà ní ọjọ́ ìsinmi?”
Następnie powiedział: —Jeśli wasze dziecko lub zwierzę wpadnie w głęboki dół, to czy natychmiast ich nie wyciągacie, nawet w święty dzień szabatu?
6 Wọn kò sì lè dá a lóhùn mọ́ sí nǹkan wọ̀nyí.
I znowu nie potrafili Mu odpowiedzieć.
7 Ó sì pa òwe kan fún àwọn tí ó pè é wá jẹun, nígbà tí ó ṣàkíyèsí bí wọ́n ti ń yan ipò ọlá; ó sì wí fún wọn pé,
Widząc zaproszonych gości, którzy wybierali sobie jak najlepsze miejsca, Jezus dał im następującą radę:
8 “Nígbà tí ẹnìkan bá pè ọ́ wá sí ibi ìyàwó, má ṣe jókòó ní ipò ọlá; kí ó má ba à jẹ́ pé, a ó pe ẹni tí ó lọ́lá jù ọ́ lọ.
—Jeśli ktoś cię zaprosi na wesele, nie zajmuj od razu najlepszego miejsca. Bo gdy wejdzie gość znaczniejszy od ciebie,
9 Nígbà tí ẹni tí ó pè ọ́ bá dé, a sì wí fún ọ pé, ‘Fún ọkùnrin yìí ní ààyè!’ Ìwọ á sì wá fi ìtìjú mú ipò ẹ̀yìn.
gospodarz domu powie ci: „Proszę, ustąp mu miejsca”. Zawstydzony, będziesz musiał wtedy zająć miejsce na szarym końcu.
10 Ṣùgbọ́n nígbà tí a bá pè ọ́, lọ kí o sì jókòó ní ipò ẹ̀yìn; nígbà tí ẹni tí ó pè ọ́ bá dé, kí ó lè wí fún ọ pé, ‘Ọ̀rẹ́, bọ́ sókè!’ Nígbà náà ni ìwọ ó ní ìyìn lójú àwọn tí ó bá ọ jókòó ti oúnjẹ.
Jeśli więc zostaniesz zaproszony, zajmij najpierw ostatnie miejsce. Gdy zjawi się pan domu, podejdzie i zaproponuje ci: „Przyjacielu, mam dla ciebie lepsze miejsce!”. W ten sposób zostaniesz uhonorowany wobec wszystkich gości.
11 Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá gbé ara rẹ̀ ga, ni a ó rẹ̀ sílẹ̀; ẹnikẹ́ni tí ó bá sì rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀, ni a ó sì gbéga.”
Każdy, kto się teraz ubiega o wyróżnienie, będzie upokorzony, a ten, kto teraz okazuje pokorę, zostanie wyróżniony.
12 Nígbà náà ni ó sì wí fún alásè tí ó pè é pé, “Nígbà tí ìwọ bá ṣe àsè má ṣe pe àwọn arákùnrin rẹ tàbí àwọn ìbátan rẹ, tàbí àwọn ọlọ́rọ̀ aládùúgbò rẹ̀; nítorí kí wọn má ṣe pè ọ́ padà láti san ẹ̀san padà.
Następnie zwrócił się do gospodarza: —Gdy wydajesz przyjęcie, nie zapraszaj wyłącznie przyjaciół, krewnych i bogatych sąsiadów—z nadzieją, że zrewanżują się tym samym.
13 Ṣùgbọ́n nígbà tí ìwọ bá ṣe àsè, pe àwọn tálákà, àwọn alábùkún ara, àwọn amúnkùn ún, àti àwọn afọ́jú:
Zaproś również ubogich, kalekich, ułomnych i niewidomych.
14 Ìwọ ó sì jẹ́ alábùkún fún; nítorí wọn kò ní ohun tí wọn ó fi san án fún ọ, ṣùgbọ́n a ó san án fún ọ ní àjíǹde, àwọn olóòtítọ́.”
Będziesz szczęśliwy, bo tacy ludzie nie mają czym ci się odwdzięczyć, a nagrodę otrzymasz po zmartwychwstaniu prawych.
15 Nígbà tí ọ̀kan nínú àwọn tí wọ́n jọ jókòó gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, ó wí fún Jesu pé, “Alábùkún ni fún ẹni tí yóò jẹ oúnjẹ àsè ní ìjọba Ọlọ́run!”
Słuchając tych słów, któryś z gości rzekł do Jezusa: —Szczęśliwy będzie ten, kto zasiądzie do uczty w królestwie Bożym!
16 Jesu dá a lóhùn pé, “Ọkùnrin kan ṣe àsè alẹ́ ńlá, ó sì pe ènìyàn púpọ̀.
Na to Jezus opowiedział mu taką historię: —Pewien człowiek zamierzał urządzić wielkie przyjęcie i rozesłał mnóstwo zaproszeń.
17 Ó sì rán ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ ní wákàtí àsè alẹ́ náà láti sọ fún àwọn tí a ti pè pé, ‘Ẹ wá; nítorí ohun gbogbo ṣetán!’
Tuż przed rozpoczęciem wysłał do zaproszonych sługę z wiadomością: „Przygotowania zakończone! Zapraszam!”.
18 “Gbogbo wọn sì bẹ̀rẹ̀ sí ṣe àwáwí ohun kan. ‘Èkínní wí fún un pé, mo ra ilẹ̀ kan, mo sì fẹ́ lọ wò ó wò, mo bẹ̀ ọ́ ṣe gáfárà fún mi.’
Wszyscy jednak zaczęli się wykręcać. Jeden powiedział: „Właśnie kupiłem pole i koniecznie muszę je obejrzeć. Proszę, wybacz mi moją nieobecność”.
19 “Èkejì sì wí pé, ‘Mo ra àjàgà màlúù márùn-ún, mo sì ń lọ wò wọ́n wò: mo bẹ̀ ọ́ ṣe gáfárà fún mi.’
Drugi powiedział: „Właśnie kupiłem pięć par wołów i akurat wychodzę je wypróbować. Proszę, wybacz mi moją nieobecność”.
20 “Ẹ̀kẹta sì wí pé, ‘Mo ṣẹ̀ṣẹ̀ gbéyàwó, nítorí náà ni èmi kò fi lè wá.’
Jeszcze inny tak się usprawiedliwił: „Właśnie się ożeniłem. Chyba rozumiesz, że nie mogę przyjść”.
21 “Ọmọ ọ̀dọ̀ náà sì padà dé, ó sọ nǹkan wọ̀nyí fún olúwa rẹ̀. Nígbà náà ni baálé ilé bínú, ó wí fún ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ pé, ‘Jáde lọ sí ìgboro, àti sí òpópó ọ̀nà, kí o sì mú àwọn tálákà, àti àwọn amúnkùn ún, àti àwọn arọ, àti àwọn afọ́jú wá sí ìhín yìí.’
Sługa wrócił i powtórzył wszystko swojemu panu. Ten, słysząc takie wymówki, rozgniewał się i nakazał: „Natychmiast idź na rynek oraz na ulice miasta i przyprowadź tu biednych, kalekich, ułomnych i niewidomych”.
22 “Ọmọ ọ̀dọ̀ náà sì wí pé, ‘Olúwa a ti ṣe bí o ti pàṣẹ, ààyè sì ń bẹ síbẹ̀.’
Po wykonaniu polecenia sługa oznajmił: „Panie, stało się tak, jak sobie życzyłeś, lecz mimo to pozostały jeszcze wolne miejsca”.
23 “Olúwa náà sì wí fún ọmọ ọ̀dọ̀ náà pé, ‘Jáde lọ sí òpópó, àti sí ọ̀nà ọgbà, kí o sì rọ̀ wọ́n láti wọlé wá, kí ilé mi lè kún.
„Wobec tego—rzekł pan—idź poza miasto i nakłaniaj napotkanych do przyjścia, tak aby mój dom był pełen gości.
24 Nítorí mo wí fún yín, ẹnikẹ́ni nínú àwọn ènìyàn wọ̀nyí tí a ti pè, kì yóò tọ́wò nínú àsè ńlá mi!’”
Z tych bowiem, których wcześniej zaprosiłem, nikt nie skosztuje przygotowanych potraw!”.
25 Àwọn ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn ń bá a lọ; ó sì yípadà, ó sì wí fún wọn pé,
Gdy Jezus udał się w dalszą drogę, razem z Nim szły nieprzebrane tłumy ludzi. Skierował więc do nich takie słowa:
26 “Bí ẹnìkan bá tọ̀ mí wá, tí kò sì kórìíra baba àti ìyá, àti aya, àti ọmọ, àti arákùnrin, àti arábìnrin, àní àti ọkàn ara rẹ̀ pẹ̀lú, kò lè ṣe ọmọ-ẹ̀yìn mi.
—Nikt nie może być moim uczniem, jeśli nie kocha Mnie bardziej niż swojego ojca, matkę, żonę, dzieci, braci czy siostry, a nawet bardziej niż samego siebie.
27 Ẹnikẹ́ni tí kò bá ru àgbélébùú rẹ̀, kí ó sì máa tọ̀ mí lẹ́yìn, kò lè ṣe ọmọ-ẹ̀yìn mi.
Kto nie bierze swojego krzyża i nie idzie ze Mną, nie może być moim uczniem.
28 “Nítorí ta ni nínú yín tí ń pète láti kọ́ ilé ìṣọ́, tí kì yóò kọ́kọ́ jókòó kí ó ṣírò iye owó rẹ̀, bí òun ní tó tí yóò fi parí rẹ̀.
Rozważcie więc swoją decyzję! Gdy ktoś z was chce rozpocząć budowę, to czy najpierw nie oblicza kosztów i nie upewnia się, że starczy mu na jej ukończenie?
29 Kí ó má ba à jẹ́ pé nígbà tí ó bá fi ìpìlẹ̀ ilé sọlẹ̀ tan, tí kò lè parí rẹ̀ mọ́, gbogbo àwọn tí ó rí i a bẹ̀rẹ̀ sí í fi í ṣe ẹlẹ́yà.
W przeciwnym razie już po położeniu fundamentów może mu zabraknąć pieniędzy. A wtedy stanie się obiektem kpin i żartów.
30 Wí pé, ‘Ọkùnrin yìí bẹ̀rẹ̀ sí kọ́ ilé, kò sì lè parí rẹ̀.’
„Cóż za brak rozsądku!”—powiedzą ludzie. „Zaczął budować i nie skończył, bo nie ma już pieniędzy”.
31 “Tàbí ọba wo ni ó ń lọ bá ọba mìíràn jà, tí kì yóò kọ́kọ́ jókòó, kí ó sì gbèrò bí yóò lè fi ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá pàdé ẹni tí ń mú ogún ẹgbẹ̀rún bọ̀ wá ko òun lójú?
Który władca rozpocznie wojnę nie zastanawiając się najpierw, czy swą dziesięciotysięczną armią zdoła pokonać nadciągające dwadzieścia tysięcy żołnierzy wroga?
32 Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, nígbà tí onítọ̀hún bá sì wà ní òkèrè, òun a rán ikọ̀ sí i, a sì bẹ̀rẹ̀ àdéhùn àlàáfíà.
Jeśli nie jest w stanie, rozpoczyna rokowania pokojowe, dopóki nieprzyjaciel jest jeszcze daleko.
33 Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni, ẹnikẹ́ni tí ó wù kí ó ṣe nínú yín, tí kò kọ ohun gbogbo tí ó ní sílẹ̀, kò lè ṣe ọmọ-ẹ̀yìn mi.
Nikt z was nie może więc zostać moim uczniem, jeśli nie wyrzeknie się dla Mnie wszystkiego, co ma.
34 “Iyọ̀ dára: ṣùgbọ́n bí iyọ̀ bá di òbu, kín ni a ó fi mú un dùn?
Sól jest dobra—mówił dalej Jezus—lecz jeśli utraci swój smak, staje się bezwartościowa.
35 Kò yẹ fún ilẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò yẹ fún ààtàn; bí kò ṣe pé kí a kó o dànù. “Ẹni tí ó bá ní etí láti fi gbọ́ kí ó gbọ́.”
Do niczego już się nie nadaje, nawet do nawożenia gleby. Trzeba ją po prostu wyrzucić. Kto ma uszy, niech słucha uważnie!

< Luke 14 >