< Luke 14 >

1 Nígbà tí ó wọ ilé ọ̀kan nínú àwọn olórí Farisi lọ ní ọjọ́ ìsinmi láti jẹun, wọ́n sì ń ṣọ́ ọ.
Og det skjedde da han kom inn i en av de øverste fariseeres hus på en sabbat for å holde måltid, og de lurte på ham,
2 Sì kíyèsi i, ọkùnrin kan tí ó ní ara wíwú níwájú rẹ̀.
se, da var der en vattersottig mann like for ham.
3 Jesu sì dáhùn ó wí fún àwọn amòfin àti àwọn Farisi pé, “Ǹjẹ́ ó tọ́ láti mú ni láradá ní ọjọ́ ìsinmi, tàbí kò tọ́?”
Og Jesus tok til orde og talte til de lovkyndige og fariseerne og sa: Er det tillatt å helbrede på sabbaten, eller ikke?
4 Wọ́n sì dákẹ́. Ó sì mú un, ó mú un láradá, ó sì jẹ́ kí ó lọ.
Men de tidde. Og han tok på ham og helbredet ham, og lot ham gå.
5 Ó sì dáhùn ó sì wí fún wọn pé, “Ta ni nínú yín tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tàbí màlúù rẹ̀ yóò bọ́ sínú ihò, tí kì yóò sì fà á sókè lójúkan náà ní ọjọ́ ìsinmi?”
Og han tok atter til orde og sa til dem: Hvem av eder har en sønn eller en okse som faller i en brønn, og drar dem ikke straks op igjen på sabbatsdagen?
6 Wọn kò sì lè dá a lóhùn mọ́ sí nǹkan wọ̀nyí.
Men de var ikke i stand til å svare ham på dette.
7 Ó sì pa òwe kan fún àwọn tí ó pè é wá jẹun, nígbà tí ó ṣàkíyèsí bí wọ́n ti ń yan ipò ọlá; ó sì wí fún wọn pé,
Og han sa en lignelse til gjestene, da han la merke til hvorledes de valgte sig ut de øverste seter:
8 “Nígbà tí ẹnìkan bá pè ọ́ wá sí ibi ìyàwó, má ṣe jókòó ní ipò ọlá; kí ó má ba à jẹ́ pé, a ó pe ẹni tí ó lọ́lá jù ọ́ lọ.
Når du blir buden av nogen til bryllups, da sett dig ikke øverst ved bordet, forat ikke en gjævere enn du skal være buden,
9 Nígbà tí ẹni tí ó pè ọ́ bá dé, a sì wí fún ọ pé, ‘Fún ọkùnrin yìí ní ààyè!’ Ìwọ á sì wá fi ìtìjú mú ipò ẹ̀yìn.
og den som innbød dig og ham, skal komme og si til dig: Gi denne mann rum! og du så med skam skal komme til å sitte nederst.
10 Ṣùgbọ́n nígbà tí a bá pè ọ́, lọ kí o sì jókòó ní ipò ẹ̀yìn; nígbà tí ẹni tí ó pè ọ́ bá dé, kí ó lè wí fún ọ pé, ‘Ọ̀rẹ́, bọ́ sókè!’ Nígbà náà ni ìwọ ó ní ìyìn lójú àwọn tí ó bá ọ jókòó ti oúnjẹ.
Men når du er buden, da gå og sett dig nederst, forat han som innbød dig, kan si til dig når han kommer: Venn, kom hit, sett dig høiere op! Da får du ære i alle deres øine som sitter til bords med dig;
11 Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá gbé ara rẹ̀ ga, ni a ó rẹ̀ sílẹ̀; ẹnikẹ́ni tí ó bá sì rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀, ni a ó sì gbéga.”
for hver den sig selv ophøier, skal fornedres, og den sig selv fornedrer, skal ophøies.
12 Nígbà náà ni ó sì wí fún alásè tí ó pè é pé, “Nígbà tí ìwọ bá ṣe àsè má ṣe pe àwọn arákùnrin rẹ tàbí àwọn ìbátan rẹ, tàbí àwọn ọlọ́rọ̀ aládùúgbò rẹ̀; nítorí kí wọn má ṣe pè ọ́ padà láti san ẹ̀san padà.
Han sa også til den som hadde innbudt ham: Når du gjør gjestebud middag eller aften, da innbyd ikke dine venner eller dine brødre eller dine frender eller rike granner, forat ikke de skal be dig igjen, så du får gjengjeld!
13 Ṣùgbọ́n nígbà tí ìwọ bá ṣe àsè, pe àwọn tálákà, àwọn alábùkún ara, àwọn amúnkùn ún, àti àwọn afọ́jú:
Men når du gjør gjestebud, da be fattige, vanføre, halte, blinde!
14 Ìwọ ó sì jẹ́ alábùkún fún; nítorí wọn kò ní ohun tí wọn ó fi san án fún ọ, ṣùgbọ́n a ó san án fún ọ ní àjíǹde, àwọn olóòtítọ́.”
så er du salig; for de har ikke noget å gi dig igjen, men du skal få det igjen i de rettferdiges opstandelse.
15 Nígbà tí ọ̀kan nínú àwọn tí wọ́n jọ jókòó gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, ó wí fún Jesu pé, “Alábùkún ni fún ẹni tí yóò jẹ oúnjẹ àsè ní ìjọba Ọlọ́run!”
Da en av dem som satt med til bords, hørte dette, sa han til ham: Salig er den som får sitte til bords i Guds rike.
16 Jesu dá a lóhùn pé, “Ọkùnrin kan ṣe àsè alẹ́ ńlá, ó sì pe ènìyàn púpọ̀.
Da sa han til ham: Det var en mann som gjorde en stor nattverd og innbød mange;
17 Ó sì rán ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ ní wákàtí àsè alẹ́ náà láti sọ fún àwọn tí a ti pè pé, ‘Ẹ wá; nítorí ohun gbogbo ṣetán!’
og han sendte sin tjener ut ved den tid nattverden skulde holdes, for å si til de innbudne: Kom! for nu er det ferdig.
18 “Gbogbo wọn sì bẹ̀rẹ̀ sí ṣe àwáwí ohun kan. ‘Èkínní wí fún un pé, mo ra ilẹ̀ kan, mo sì fẹ́ lọ wò ó wò, mo bẹ̀ ọ́ ṣe gáfárà fún mi.’
Men de begynte alle som én å undskylde sig. Den første sa til ham: Jeg har kjøpt en aker og må nødvendig gå ut og se på den; jeg ber dig, ha mig undskyldt!
19 “Èkejì sì wí pé, ‘Mo ra àjàgà màlúù márùn-ún, mo sì ń lọ wò wọ́n wò: mo bẹ̀ ọ́ ṣe gáfárà fún mi.’
Og en annen sa: Jeg har kjøpt fem par okser og går ut for å prøve dem; jeg ber dig, ha mig undskyldt!
20 “Ẹ̀kẹta sì wí pé, ‘Mo ṣẹ̀ṣẹ̀ gbéyàwó, nítorí náà ni èmi kò fi lè wá.’
Og atter en annen sa: Jeg har tatt mig en hustru, og derfor kan jeg ikke komme.
21 “Ọmọ ọ̀dọ̀ náà sì padà dé, ó sọ nǹkan wọ̀nyí fún olúwa rẹ̀. Nígbà náà ni baálé ilé bínú, ó wí fún ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ pé, ‘Jáde lọ sí ìgboro, àti sí òpópó ọ̀nà, kí o sì mú àwọn tálákà, àti àwọn amúnkùn ún, àti àwọn arọ, àti àwọn afọ́jú wá sí ìhín yìí.’
Og tjeneren kom og fortalte sin herre dette. Da blev husbonden harm og sa til tjeneren: Gå i hast ut på byens gater og streder, og før herinn de fattige og vanføre og blinde og halte!
22 “Ọmọ ọ̀dọ̀ náà sì wí pé, ‘Olúwa a ti ṣe bí o ti pàṣẹ, ààyè sì ń bẹ síbẹ̀.’
Og tjeneren sa: Herre! det er gjort som du bød, og der er ennu rum.
23 “Olúwa náà sì wí fún ọmọ ọ̀dọ̀ náà pé, ‘Jáde lọ sí òpópó, àti sí ọ̀nà ọgbà, kí o sì rọ̀ wọ́n láti wọlé wá, kí ilé mi lè kún.
Da sa herren til tjeneren: Gå ut på veiene og ved gjerdene og nød dem til å komme inn, forat mitt hus kan bli fullt!
24 Nítorí mo wí fún yín, ẹnikẹ́ni nínú àwọn ènìyàn wọ̀nyí tí a ti pè, kì yóò tọ́wò nínú àsè ńlá mi!’”
For jeg sier eder at ingen av de menn som var innbudt, skal smake min nattverd.
25 Àwọn ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn ń bá a lọ; ó sì yípadà, ó sì wí fún wọn pé,
Og meget folk vandret sammen med ham. Og han vendte sig og sa til dem:
26 “Bí ẹnìkan bá tọ̀ mí wá, tí kò sì kórìíra baba àti ìyá, àti aya, àti ọmọ, àti arákùnrin, àti arábìnrin, àní àti ọkàn ara rẹ̀ pẹ̀lú, kò lè ṣe ọmọ-ẹ̀yìn mi.
Om nogen kommer til mig og ikke hater sin far og mor og hustru og barn og brødre og søstre, ja endog sitt eget liv, han kan ikke være min disippel.
27 Ẹnikẹ́ni tí kò bá ru àgbélébùú rẹ̀, kí ó sì máa tọ̀ mí lẹ́yìn, kò lè ṣe ọmọ-ẹ̀yìn mi.
Og den som ikke bærer sitt kors og følger efter mig, han kan ikke være min disippel.
28 “Nítorí ta ni nínú yín tí ń pète láti kọ́ ilé ìṣọ́, tí kì yóò kọ́kọ́ jókòó kí ó ṣírò iye owó rẹ̀, bí òun ní tó tí yóò fi parí rẹ̀.
For hvem av eder som vil bygge et tårn, setter sig ikke først ned og regner efter hvad det vil koste, om han har nok til å fullføre det med,
29 Kí ó má ba à jẹ́ pé nígbà tí ó bá fi ìpìlẹ̀ ilé sọlẹ̀ tan, tí kò lè parí rẹ̀ mọ́, gbogbo àwọn tí ó rí i a bẹ̀rẹ̀ sí í fi í ṣe ẹlẹ́yà.
forat ikke, når han har lagt grunnen og ikke er i stand til å fullføre det, alle de som ser det, skal begynne å spotte ham og si:
30 Wí pé, ‘Ọkùnrin yìí bẹ̀rẹ̀ sí kọ́ ilé, kò sì lè parí rẹ̀.’
Denne mann begynte å bygge, og var ikke i stand til å fullføre det?
31 “Tàbí ọba wo ni ó ń lọ bá ọba mìíràn jà, tí kì yóò kọ́kọ́ jókòó, kí ó sì gbèrò bí yóò lè fi ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá pàdé ẹni tí ń mú ogún ẹgbẹ̀rún bọ̀ wá ko òun lójú?
Eller hvilken konge som drar ut for å møte en annen konge i strid, setter sig ikke først ned og rådslår om han med ti tusen er i stand til å møte den som kommer imot ham med tyve tusen?
32 Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, nígbà tí onítọ̀hún bá sì wà ní òkèrè, òun a rán ikọ̀ sí i, a sì bẹ̀rẹ̀ àdéhùn àlàáfíà.
Men kan han ikke det, da skikker han sendemenn til ham, mens han ennu er langt borte, og tinger om fred.
33 Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni, ẹnikẹ́ni tí ó wù kí ó ṣe nínú yín, tí kò kọ ohun gbogbo tí ó ní sílẹ̀, kò lè ṣe ọmọ-ẹ̀yìn mi.
Således kan da ingen av eder være min disippel uten at han opgir alt det han eier.
34 “Iyọ̀ dára: ṣùgbọ́n bí iyọ̀ bá di òbu, kín ni a ó fi mú un dùn?
Salt er en god ting, men når også saltet mister sin kraft, hvad skal det da saltes med?
35 Kò yẹ fún ilẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò yẹ fún ààtàn; bí kò ṣe pé kí a kó o dànù. “Ẹni tí ó bá ní etí láti fi gbọ́ kí ó gbọ́.”
Det duer hverken i jord eller i gjødsel; det blir kastet ut. Den som har ører å høre med, han høre!

< Luke 14 >