< Luke 13 >

1 Àwọn kan sì wá ní àkókò náà tí ó sọ ti àwọn ará Galili fún un, ẹ̀jẹ̀ ẹni tí Pilatu dàpọ̀ mọ́ ẹbọ wọn.
اَپَرَنْچَ پِیلاتو ییشاں گالِیلِییاناں رَکْتانِ بَلِیناں رَکْتَیح سَہامِشْرَیَتْ تیشاں گالِیلِییاناں ورِتّانْتَں کَتِپَیَجَنا اُپَسْتھاپْیَ یِیشَوے کَتھَیاماسُح۔
2 Jesu sì dáhùn ó wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ṣe bí àwọn ará Galili wọ̀nyí ṣe ẹlẹ́ṣẹ̀ ju gbogbo àwọn ará Galili lọ, nítorí wọ́n jẹ irú ìyà bá-wọ̀n-ọn-nì?
تَتَح سَ پْرَتْیُواچَ تیشاں لوکانامْ ایتادرِشِی دُرْگَتِ رْگھَٹِتا تَتْکارَنادْ یُویَں کِمَنْییبھْیو گالِیلِیییبھْیوپْیَدھِکَپاپِنَسْتانْ بودھَدھْوے؟
3 Mo wí fún yín, bí kò ṣe pé ẹ̀yin pẹ̀lú ronúpìwàdà, gbogbo yín ni yóò ṣègbé bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́.
یُشْمانَہَں وَدامِ تَتھا نَ کِنْتُ مَنَحسُ نَ پَراوَرْتِّتیشُ یُویَمَپِ تَتھا نَںکْشْیَتھَ۔
4 Tàbí àwọn méjìdínlógún, tí ilé ìṣọ́ ní Siloamu wó lù, tí ó sì pa wọ́n, ẹ̀yin ṣe bí wọ́n ṣe ẹlẹ́ṣẹ̀ ju gbogbo àwọn ènìyàn tí ń bẹ ní Jerusalẹmu lọ?
اَپَرَنْچَ شِیلوہَنامْنَ اُچَّگرِہَسْیَ پَتَنادْ یےشْٹادَشَجَنا مرِتاسْتے یِرُوشالَمِ نِواسِسَرْوَّلوکیبھْیودھِکاپَرادھِنَح کِں یُویَمِتْیَں بودھَدھْوے؟
5 Mo wí fún yín, bí kò ṣe pé ẹ̀yin ronúpìwàdà, gbogbo yín ni yóò ṣègbé bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́.”
یُشْمانَہَں وَدامِ تَتھا نَ کِنْتُ مَنَحسُ نَ پَرِوَرْتِّتیشُ یُویَمَپِ تَتھا نَںکْشْیَتھَ۔
6 Ó sì pa òwe yìí fún wọn pé, “Ọkùnrin kan ní igi ọ̀pọ̀tọ́ kan tí a gbìn sí ọgbà àjàrà rẹ̀; ó sì dé, ó ń wá èso lórí rẹ̀, kò sì rí nǹkan.
اَنَنْتَرَں سَ اِماں درِشْٹانْتَکَتھامَکَتھَیَدْ ایکو جَنو دْراکْشاکْشیتْرَمَدھْیَ ایکَمُڈُمْبَرَورِکْشَں روپِتَوانْ۔ پَشْچاتْ سَ آگَتْیَ تَسْمِنْ پھَلانِ گَویشَیاماسَ،
7 Ó sì wí fún olùṣọ́gbà rẹ̀ pé, ‘Sá à wò ó, láti ọdún mẹ́ta ni èmi ti ń wá í wo èso lórí igi ọ̀pọ̀tọ́ yìí, èmi kò sì rí nǹkan: ké e lulẹ̀; èéṣe tí ó fi ń gbilẹ̀ lásán pẹ̀lú?’
کِنْتُ پھَلاپْراپْتیح کارَنادْ اُدْیانَکارَں بھرِتْیَں جَگادَ، پَشْیَ وَتْسَرَتْرَیَں یاوَداگَتْیَ ایتَسْمِنُّڈُمْبَرَتَرَو کْشَلانْیَنْوِچّھامِ، کِنْتُ نَیکَمَپِ پْرَپْنومِ تَرُرَیَں کُتو ورِتھا سْتھانَں وْیاپْیَ تِشْٹھَتِ؟ اینَں چھِنْدھِ۔
8 “Ó sì dáhùn ó wí fún un pé, ‘Olúwa, jọ̀wọ́ rẹ̀ ní ọdún yìí pẹ̀lú, títí èmi ó fi tu ilẹ̀ ìdí rẹ̀ yíká, títí èmi ó sì fi bu ìlẹ̀dú sí i.
تَتو بھرِتْیَح پْرَتْیُواچَ، ہے پْرَبھو پُنَرْوَرْشَمیکَں سْتھاتُمْ آدِشَ؛ ایتَسْیَ مُولَسْیَ چَتُرْدِکْشُ کھَنِتْواہَمْ آلَوالَں سْتھاپَیامِ۔
9 Bí ó bá sì so èso, o dara bẹ́ẹ̀: bí kò bá sì so, ǹjẹ́ lẹ́yìn èyí nì kí ìwọ kí ó ké e lulẹ̀.’”
تَتَح پھَلِتُں شَکْنوتِ یَدِ نَ پھَلَتِ تَرْہِ پَشْچاتْ چھیتْسْیَسِ۔
10 Ó sì ń kọ́ni nínú Sinagọgu kan ní ọjọ́ ìsinmi.
اَتھَ وِشْرامَوارے بھَجَنَگیہے یِیشُرُپَدِشَتِ
11 Sì kíyèsi i, obìnrin kan wà níbẹ̀ tí ó ní ẹ̀mí àìlera, láti ọdún méjìdínlógún wá, ẹni tí ó tẹ̀ tán, tí kò le gbé ara rẹ̀ sókè bí ó ti wù kí ó ṣe.
تَسْمِتْ سَمَیے بھُوتَگْرَسْتَتْواتْ کُبْجِیبھُویاشْٹادَشَوَرْشانِ یاوَتْ کیناپْیُپایینَ رِجُ رْبھَوِتُں نَ شَکْنوتِ یا دُرْبَّلا سْتْرِی،
12 Nígbà tí Jesu rí i, ó pè é sí ọ̀dọ̀, ó sì wí fún un pé, “Obìnrin yìí, a tú ọ sílẹ̀ lọ́wọ́ àìlera rẹ.”
تاں تَتْروپَسْتھِتاں وِلوکْیَ یِیشُسْتاماہُویَ کَتھِتَوانْ ہے نارِ تَوَ دَورْبَّلْیاتْ تْوَں مُکْتا بھَوَ۔
13 Ó sì fi ọwọ́ rẹ̀ lé e, Lójúkan náà a sì ti sọ ọ́ di títọ́, ó sì ń yin Ọlọ́run lógo.
تَتَح پَرَں تَسْیا گاتْرے ہَسْتارْپَنَماتْراتْ سا رِجُرْبھُوتْویشْوَرَسْیَ دھَنْیَوادَں کَرْتُّماریبھے۔
14 Olórí Sinagọgu sì kún fún ìrunú, nítorí tí Jesu mú ni láradá ní ọjọ́ ìsinmi, ó sì wí fún ìjọ ènìyàn pé, ọjọ́ mẹ́fà ní ń bẹ tí a fi í ṣiṣẹ́, nínú wọn ni kí ẹ̀yin kí ó wá kí á ṣe dídá ara yín, kí ó má ṣe ní ọjọ́ ìsinmi.
کِنْتُ وِشْرامَوارے یِیشُنا تَسْیاح سْواسْتھْیَکَرَنادْ بھَجَنَگیہَسْیادھِپَتِح پْرَکُپْیَ لوکانْ اُواچَ، شَٹْسُ دِنیشُ لوکَیح کَرْمَّ کَرْتَّوْیَں تَسْمادّھیتوح سْواسْتھْیارْتھَں تیشُ دِنیشُ آگَچّھَتَ، وِشْرامَوارے ماگَچّھَتَ۔
15 Nígbà náà ni Olúwa dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Ẹ̀yin àgàbàgebè, olúkúlùkù yín kì í tú màlúù tàbí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ kúrò ní ibùso, kì í sì í fà á lọ mu omi ní ọjọ́ ìsinmi.
تَدا پَبھُح پْرَتْیُواچَ رے کَپَٹِنو یُشْماکَمْ ایکَیکو جَنو وِشْرامَوارے سْوِییَں سْوِییَں ورِشَبھَں گَرْدَبھَں وا بَنْدھَنانْموچَیِتْوا جَلَں پایَیِتُں کِں نَ نَیَتِ؟
16 Kò sì yẹ kí a tú obìnrin yìí tí í ṣe ọmọbìnrin Abrahamu sílẹ̀ ní ìdè yìí ní ọjọ́ ìsinmi, ẹni tí Satani ti dè, sá à wò ó láti ọdún méjìdínlógún yìí wá?”
تَرْہْیاشْٹادَشَوَتْسَرانْ یاوَتْ شَیتانا بَدّھا اِبْراہِیمَح سَنْتَتِرِیَں نارِی کِں وِشْرامَوارے نَ موچَیِتَوْیا؟
17 Nígbà tí ó sì wí nǹkan wọ̀nyí, ojú ti gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀, gbogbo ìjọ ènìyàn sì yọ̀ fún ohun ìyanu gbogbo tí ó ṣe.
ایشُ واکْییشُ کَتھِتیشُ تَسْیَ وِپَکْشاح سَلَجّا جاتاح کِنْتُ تینَ کرِتَسَرْوَّمَہاکَرْمَّکارَناتْ لوکَنِوَہَح سانَنْدوبھَوَتْ۔
18 Ó sì wí pé, “Kín ni ìjọba Ọlọ́run jọ? Kín ni èmi ó sì fiwé?
اَنَنْتَرَں سووَدَدْ اِیشْوَرَسْیَ راجْیَں کَسْیَ سَدرِشَں؟ کینَ تَدُپَماسْیامِ؟
19 Ó dàbí hóró musitadi, tí ọkùnrin kan mú, tí ó sì sọ sínú ọgbà rẹ̀; tí ó sì hù, ó sì di igi ńlá; àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run sì ń gbé orí ẹ̀ka rẹ̀.”
یَتْ سَرْشَپَبِیجَں گرِہِیتْوا کَشْچِجَّنَ اُدْیانَ اُپْتَوانْ تَدْ بِیجَمَنْکُرِتَں سَتْ مَہاورِکْشوجایَتَ، تَتَسْتَسْیَ شاکھاسُ وِہایَسِییَوِہَگا آگَتْیَ نْیُوشُح، تَدْراجْیَں تادرِشینَ سَرْشَپَبِیجینَ تُلْیَں۔
20 Ó sì tún wí pé, “Kín ni èmi ìbá fi ìjọba Ọlọ́run wé?
پُنَح کَتھَیاماسَ، اِیشْوَرَسْیَ راجْیَں کَسْیَ سَدرِشَں وَدِشْیامِ؟ یَتْ کِنْوَں کاچِتْ سْتْرِی گرِہِیتْوا دْرونَتْرَیَپَرِمِتَگودھُومَچُورْنیشُ سْتھاپَیاماسَ،
21 Ó dàbí ìwúkàrà, tí obìnrin kan mú, tí ó fi sínú òsùwọ̀n ìyẹ̀fun mẹ́ta, títí gbogbo rẹ̀ ó fi di wíwú.”
تَتَح کْرَمینَ تَتْ سَرْوَّگودھُومَچُورْنَں وْیاپْنوتِ، تَسْیَ کِنْوَسْیَ تُلْیَمْ اِیشْوَرَسْیَ راجْیَں۔
22 Ó sì ń la àárín ìlú àti ìletò lọ, ó ń kọ́ni, ó sì ń rìn lọ sí Jerusalẹmu.
تَتَح سَ یِرُوشالَمْنَگَرَں پْرَتِ یاتْراں کرِتْوا نَگَرے نَگَرے گْرامے گْرامے سَمُپَدِشَنْ جَگامَ۔
23 Ẹnìkan sì bi í pé, Olúwa, díẹ̀ ha kọ ni àwọn tí a ó gbàlà? Ó sì wí fún wọn pé,
تَدا کَشْچِجَّنَسْتَں پَپْرَچّھَ، ہے پْرَبھو کِں کیوَلَمْ اَلْپے لوکاح پَرِتْراسْیَنْتے؟
24 “Ẹ làkàkà láti gba ojú ọ̀nà tóóró wọlé, nítorí mo wí fún yín, ènìyàn púpọ̀ ni yóò wá ọ̀nà láti wọ̀ ọ́, wọn kì yóò sì lè wọlé.
تَتَح سَ لوکانْ اُواچَ، سَںکِیرْنَدْوارینَ پْرَویشْٹُں یَتَگھْوَں، یَتوہَں یُشْمانْ وَدامِ، بَہَوَح پْرَویشْٹُں چیشْٹِشْیَنْتے کِنْتُ نَ شَکْشْیَنْتِ۔
25 Nígbà tí baálé ilé bá dìde lẹ́ẹ̀kan fùú, tí ó bá sí ti ìlẹ̀kùn, ẹ̀yin ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í dúró lóde, tí ẹ ó máa kan ìlẹ̀kùn, wí pé, ‘Olúwa, Olúwa, ṣí i fún wa!’ “Òun ó sì dáhùn wí fún yín pé, ‘Èmi kò mọ̀ ibi tí ẹ̀yin ti wá.’ Bẹ́ẹ̀ ni èmi kò mọ̀ yín.
گرِہَپَتِنوتّھایَ دْوارے رُدّھے سَتِ یَدِ یُویَں بَہِح سْتھِتْوا دْوارَماہَتْیَ وَدَتھَ، ہے پْرَبھو ہے پْرَبھو اَسْمَتْکارَنادْ دْوارَں موچَیَتُ، تَتَح سَ اِتِ پْرَتِوَکْشْیَتِ، یُویَں کُتْرَتْیا لوکا اِتْیَہَں نَ جانامِ۔
26 “Nígbà náà ni ẹ̀yin ó bẹ̀rẹ̀ sí wí pé, ‘Àwa ti jẹ, àwa sì ti mu níwájú rẹ, ìwọ sì kọ́ni ní ìgboro ìlú wa.’
تَدا یُویَں وَدِشْیَتھَ، تَوَ ساکْشادْ وَیَں بھےجَنَں پانَنْچَ کرِتَوَنْتَح، تْوَنْچاسْماکَں نَگَرَسْیَ پَتھِ سَمُپَدِشْٹَوانْ۔
27 “Òun ó sì wí pé, ‘Èmi wí fún yín èmi kò mọ̀ ibi tí ẹ̀yin ti wá; ẹ lọ kúrò lọ́dọ̀ mi gbogbo ẹ̀yin tí ń ṣiṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀.’
کِنْتُ سَ وَکْشْیَتِ، یُشْمانَہَں وَدامِ، یُویَں کُتْرَتْیا لوکا اِتْیَہَں نَ جانامِ؛ ہے دُراچارِنو یُویَں مَتّو دُورِیبھَوَتَ۔
28 “Níbẹ̀ ni ẹkún àti ìpayínkeke yóò wà, nígbà tí ẹ̀yin ó rí Abrahamu, àti Isaaki, àti Jakọbu, àti gbogbo àwọn wòlíì, ní ìjọba Ọlọ́run, tí a ó sì ti ẹ̀yin sóde.
تَدا اِبْراہِیمَں اِسْہاکَں یاکُوبَنْچَ سَرْوَّبھَوِشْیَدْوادِنَشْچَ اِیشْوَرَسْیَ راجْیَں پْراپْتانْ سْواںشْچَ بَہِشْکرِتانْ درِشْٹْوا یُویَں رودَنَں دَنْتَیرْدَنْتَگھَرْشَنَنْچَ کَرِشْیَتھَ۔
29 Wọn ó sì ti ilẹ̀ ìlà-oòrùn, àti ìwọ̀-oòrùn wá, àti láti àríwá, àti gúúsù wá, wọn ó sì jókòó ní ìjọba Ọlọ́run.
اَپَرَنْچَ پُورْوَّپَشْچِمَدَکْشِنوتَّرَدِگْبھْیو لوکا آگَتْیَ اِیشْوَرَسْیَ راجْیے نِوَتْسْیَنْتِ۔
30 Sì wò ó, àwọn ẹni ẹ̀yìn ń bẹ tí yóò di ẹni iwájú, àwọn ẹni iwájú ń bẹ tí yóò di ẹni ẹ̀yìn.”
پَشْیَتیتّھَں شیشِییا لوکا اَگْرا بھَوِشْیَنْتِ، اَگْرِییا لوکاشْچَ شیشا بھَوِشْیَنْتِ۔
31 Ní wákàtí kan náà, díẹ̀ nínú àwọn Farisi tọ̀ ọ́ wá, wọ́n sì wí fún un pé, “Jáde, kí ìwọ sì lọ kúrò níhìn-ín yìí: nítorí Herodu ń fẹ́ pa ọ́.”
اَپَرَنْچَ تَسْمِنْ دِنے کِیَنْتَح پھِرُوشِنَ آگَتْیَ یِیشُں پْروچُح، بَہِرْگَچّھَ، سْتھانادَسْماتْ پْرَسْتھانَں کُرُ، ہیرودْ تْواں جِگھاںسَتِ۔
32 Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ, kí ẹ̀yin sì sọ fún kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ náà pé, ‘Kíyèsi i, èmi ń lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde, èmi ń ṣe ìmúláradá lónìí àti lọ́la, àti ní ọjọ́ mẹ́ta èmi ó ṣe àṣepé.’
تَتَح سَ پْرَتْیَووچَتْ پَشْیَتادْیَ شْوَشْچَ بھُوتانْ وِہاپْیَ روگِنوروگِنَح کرِتْوا ترِتِیییہْنِ سیتْسْیامِ، کَتھامیتاں یُویَمِتْوا تَں بھُورِمایَں وَدَتَ۔
33 Ṣùgbọ́n èmi kò jẹ́ má rìn lónìí, àti lọ́la, àti ní ọ̀túnla: dájúdájú wòlíì kan ki yóò ṣègbé lẹ́yìn odi Jerusalẹmu.
تَتْراپْیَدْیَ شْوَح پَرَشْوَشْچَ مَیا گَمَناگَمَنے کَرْتَّوْیے، یَتو ہیتو رْیِرُوشالَمو بَہِح کُتْراپِ کوپِ بھَوِشْیَدْوادِی نَ گھانِشْیَتے۔
34 “Jerusalẹmu, Jerusalẹmu, ìwọ tí o pa àwọn wòlíì, tí o sì sọ òkúta lu àwọn tí a rán sí ọ pa; nígbà mélòó ni èmi ń fẹ́ ràgà bo àwọn ọmọ rẹ, bí àgbébọ̀ adìyẹ ti í ràgà bo àwọn ọmọ rẹ̀ lábẹ́ apá rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fẹ́!
ہے یِرُوشالَمْ ہے یِرُوشالَمْ تْوَں بھَوِشْیَدْوادِنو ہَںسِ تَوانْتِکے پْریرِتانْ پْرَسْتَرَیرْمارَیَسِ چَ، یَتھا کُکُّٹِی نِجَپَکْشادھَح سْوَشاوَکانْ سَںگرِہْلاتِ، تَتھاہَمَپِ تَوَ شِشُونْ سَںگْرَہِیتُں کَتِوارانْ اَیچّھَں کِنْتُ تْوَں نَیچّھَح۔
35 Sá wò ó, a fi ilé yín sílẹ̀ fún yín ní ahoro. Lóòtítọ́ ni mo sì wí fún yín, ẹ̀yin kì yóò sì rí mi títí yóò fi di àkókò tí ẹ̀yin ó wí pé, ‘Olùbùkún ni ẹni tí ó ń bọ̀ wá ní orúkọ Olúwa.’”
پَشْیَتَ یُشْماکَں واسَسْتھانانِ پْروچّھِدْیَمانانِ پَرِتْیَکْتانِ چَ بھَوِشْیَنْتِ؛ یُشْمانَہَں یَتھارْتھَں وَدامِ، یَح پْرَبھو رْنامْناگَچّھَتِ سَ دھَنْیَ اِتِ واچَں یاوَتْکالَں نَ وَدِشْیَتھَ، تاوَتْکالَں یُویَں ماں نَ دْرَکْشْیَتھَ۔

< Luke 13 >