< Luke 13 >
1 Àwọn kan sì wá ní àkókò náà tí ó sọ ti àwọn ará Galili fún un, ẹ̀jẹ̀ ẹni tí Pilatu dàpọ̀ mọ́ ẹbọ wọn.
Și erau prezenți în acel timp unii care i-au spus despre galileenii al căror sânge Pilat îl amestecase cu sacrificiile lor.
2 Jesu sì dáhùn ó wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ṣe bí àwọn ará Galili wọ̀nyí ṣe ẹlẹ́ṣẹ̀ ju gbogbo àwọn ará Galili lọ, nítorí wọ́n jẹ irú ìyà bá-wọ̀n-ọn-nì?
Și Isus, răspunzând, le-a zis: Gândiți că acești galileeni au fost mai păcătoși decât toți galileenii, pentru că au suferit astfel de lucruri?
3 Mo wí fún yín, bí kò ṣe pé ẹ̀yin pẹ̀lú ronúpìwàdà, gbogbo yín ni yóò ṣègbé bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́.
Vă spun: Nu; ci, dacă nu vă pocăiți, toți veți pieri la fel.
4 Tàbí àwọn méjìdínlógún, tí ilé ìṣọ́ ní Siloamu wó lù, tí ó sì pa wọ́n, ẹ̀yin ṣe bí wọ́n ṣe ẹlẹ́ṣẹ̀ ju gbogbo àwọn ènìyàn tí ń bẹ ní Jerusalẹmu lọ?
Sau acei optsprezece peste care a căzut turnul din Siloam și i-a ucis, gândiți că ei au fost mai păcătoși decât toți oamenii care locuiau în Ierusalim?
5 Mo wí fún yín, bí kò ṣe pé ẹ̀yin ronúpìwàdà, gbogbo yín ni yóò ṣègbé bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́.”
Vă spun: Nu; ci, dacă nu vă pocăiți, toți veți pieri la fel.
6 Ó sì pa òwe yìí fún wọn pé, “Ọkùnrin kan ní igi ọ̀pọ̀tọ́ kan tí a gbìn sí ọgbà àjàrà rẹ̀; ó sì dé, ó ń wá èso lórí rẹ̀, kò sì rí nǹkan.
A spus și această parabolă: Cineva avea un smochin plantat în via lui; și a venit căutând rod în el și nu a găsit.
7 Ó sì wí fún olùṣọ́gbà rẹ̀ pé, ‘Sá à wò ó, láti ọdún mẹ́ta ni èmi ti ń wá í wo èso lórí igi ọ̀pọ̀tọ́ yìí, èmi kò sì rí nǹkan: ké e lulẹ̀; èéṣe tí ó fi ń gbilẹ̀ lásán pẹ̀lú?’
Atunci i-a spus grădinarului: Iată, de trei ani vin căutând rod în acest smochin și nu găsesc; taie-l; de ce să ocupe pământul degeaba?
8 “Ó sì dáhùn ó wí fún un pé, ‘Olúwa, jọ̀wọ́ rẹ̀ ní ọdún yìí pẹ̀lú, títí èmi ó fi tu ilẹ̀ ìdí rẹ̀ yíká, títí èmi ó sì fi bu ìlẹ̀dú sí i.
Iar el, răspunzând, i-a zis: Domnule, lasă-l și acest an, până voi săpa în jurul lui și îi voi pune gunoi;
9 Bí ó bá sì so èso, o dara bẹ́ẹ̀: bí kò bá sì so, ǹjẹ́ lẹ́yìn èyí nì kí ìwọ kí ó ké e lulẹ̀.’”
Și dacă va face rod, bine; și dacă nu, după aceea îl vei tăia.
10 Ó sì ń kọ́ni nínú Sinagọgu kan ní ọjọ́ ìsinmi.
Și îi învăța în una din sinagogi în sabat.
11 Sì kíyèsi i, obìnrin kan wà níbẹ̀ tí ó ní ẹ̀mí àìlera, láti ọdún méjìdínlógún wá, ẹni tí ó tẹ̀ tán, tí kò le gbé ara rẹ̀ sókè bí ó ti wù kí ó ṣe.
Și iată, era o femeie care avea un duh de neputință de optsprezece ani; și era gârbovă și nu putea nicidecum să se ridice.
12 Nígbà tí Jesu rí i, ó pè é sí ọ̀dọ̀, ó sì wí fún un pé, “Obìnrin yìí, a tú ọ sílẹ̀ lọ́wọ́ àìlera rẹ.”
Și Isus, văzând-o, a chemat-o la el și i-a spus: Femeie, ești dezlegată de neputința ta.
13 Ó sì fi ọwọ́ rẹ̀ lé e, Lójúkan náà a sì ti sọ ọ́ di títọ́, ó sì ń yin Ọlọ́run lógo.
Și a pus mâinile peste ea; și imediat a fost îndreptată și glorifica pe Dumnezeu.
14 Olórí Sinagọgu sì kún fún ìrunú, nítorí tí Jesu mú ni láradá ní ọjọ́ ìsinmi, ó sì wí fún ìjọ ènìyàn pé, ọjọ́ mẹ́fà ní ń bẹ tí a fi í ṣiṣẹ́, nínú wọn ni kí ẹ̀yin kí ó wá kí á ṣe dídá ara yín, kí ó má ṣe ní ọjọ́ ìsinmi.
Și conducătorul sinagogii a răspuns, fiind supărat, pentru că Isus vindecase în sabat și a spus oamenilor: Sunt șase zile în care ar trebui să se lucreze; de aceea în acestea veniți și fiți vindecați și nu în ziua sabatului.
15 Nígbà náà ni Olúwa dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Ẹ̀yin àgàbàgebè, olúkúlùkù yín kì í tú màlúù tàbí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ kúrò ní ibùso, kì í sì í fà á lọ mu omi ní ọjọ́ ìsinmi.
Atunci Domnul i-a răspuns și a zis: Fățarnicule, nu își dezleagă fiecare din voi în sabat boul sau măgarul de la iesle și îl duce la adăpat?
16 Kò sì yẹ kí a tú obìnrin yìí tí í ṣe ọmọbìnrin Abrahamu sílẹ̀ ní ìdè yìí ní ọjọ́ ìsinmi, ẹni tí Satani ti dè, sá à wò ó láti ọdún méjìdínlógún yìí wá?”
Și nu trebuia această femeie, fiind o fiică a lui Avraam, pe care Satan a legat-o, iată, de optsprezece ani, să fie dezlegată de această legătură în ziua sabatului?
17 Nígbà tí ó sì wí nǹkan wọ̀nyí, ojú ti gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀, gbogbo ìjọ ènìyàn sì yọ̀ fún ohun ìyanu gbogbo tí ó ṣe.
Și după ce a spus acestea, toți potrivnicii lui au fost rușinați; și toți oamenii se bucurau de toate lucrurile glorioase care au fost făcute de el.
18 Ó sì wí pé, “Kín ni ìjọba Ọlọ́run jọ? Kín ni èmi ó sì fiwé?
Atunci el a spus: Cu ce se aseamănă împărăția lui Dumnezeu? Și cu ce o voi asemăna?
19 Ó dàbí hóró musitadi, tí ọkùnrin kan mú, tí ó sì sọ sínú ọgbà rẹ̀; tí ó sì hù, ó sì di igi ńlá; àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run sì ń gbé orí ẹ̀ka rẹ̀.”
Se aseamănă cu un grăunte de muștar, pe care un om l-a luat și l-a aruncat în grădina sa; și a crescut și s-a făcut un copac mare; și păsările cerului au cuibărit în ramurile lui.
20 Ó sì tún wí pé, “Kín ni èmi ìbá fi ìjọba Ọlọ́run wé?
Și a spus din nou: Cu ce voi asemăna împărăția lui Dumnezeu?
21 Ó dàbí ìwúkàrà, tí obìnrin kan mú, tí ó fi sínú òsùwọ̀n ìyẹ̀fun mẹ́ta, títí gbogbo rẹ̀ ó fi di wíwú.”
Se aseamănă cu dospeala pe care o femeie, luând-o, a ascuns-o în trei măsuri de făină, până când a dospit totul.
22 Ó sì ń la àárín ìlú àti ìletò lọ, ó ń kọ́ni, ó sì ń rìn lọ sí Jerusalẹmu.
Și trecea prin cetăți și sate, învățând și călătorind spre Ierusalim.
23 Ẹnìkan sì bi í pé, Olúwa, díẹ̀ ha kọ ni àwọn tí a ó gbàlà? Ó sì wí fún wọn pé,
Atunci cineva i-a spus: Doamne, sunt puțini cei salvați? Și le-a zis:
24 “Ẹ làkàkà láti gba ojú ọ̀nà tóóró wọlé, nítorí mo wí fún yín, ènìyàn púpọ̀ ni yóò wá ọ̀nà láti wọ̀ ọ́, wọn kì yóò sì lè wọlé.
Străduiți-vă să intrați prin poarta cea strâmtă, pentru că, vă spun, mulți vor căuta să intre și nu vor fi în stare.
25 Nígbà tí baálé ilé bá dìde lẹ́ẹ̀kan fùú, tí ó bá sí ti ìlẹ̀kùn, ẹ̀yin ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í dúró lóde, tí ẹ ó máa kan ìlẹ̀kùn, wí pé, ‘Olúwa, Olúwa, ṣí i fún wa!’ “Òun ó sì dáhùn wí fún yín pé, ‘Èmi kò mọ̀ ibi tí ẹ̀yin ti wá.’ Bẹ́ẹ̀ ni èmi kò mọ̀ yín.
Când stăpânul casei se va ridica și va închide ușa și veți începe să stați în picioare afară și să bateți la ușă, spunând: Doamne, Doamne, deschide-ne; și, răspunzând, vă va zice: Nu vă cunosc și nici nu știu de unde sunteți;
26 “Nígbà náà ni ẹ̀yin ó bẹ̀rẹ̀ sí wí pé, ‘Àwa ti jẹ, àwa sì ti mu níwájú rẹ, ìwọ sì kọ́ni ní ìgboro ìlú wa.’
Atunci veți începe să spuneți: Am mâncat și am băut în prezența ta și ne-ai învățat pe străzile noastre.
27 “Òun ó sì wí pé, ‘Èmi wí fún yín èmi kò mọ̀ ibi tí ẹ̀yin ti wá; ẹ lọ kúrò lọ́dọ̀ mi gbogbo ẹ̀yin tí ń ṣiṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀.’
Iar el va zice: Vă spun că nu știu de unde sunteți; depărtați-vă de la mine, toți lucrătorii nelegiuirii.
28 “Níbẹ̀ ni ẹkún àti ìpayínkeke yóò wà, nígbà tí ẹ̀yin ó rí Abrahamu, àti Isaaki, àti Jakọbu, àti gbogbo àwọn wòlíì, ní ìjọba Ọlọ́run, tí a ó sì ti ẹ̀yin sóde.
Acolo va fi plânsul și scrâșnirea dinților, când veți vedea pe Avraam și pe Isaac și pe Iacob și pe toți profeții în împărăția lui Dumnezeu, iar pe voi aruncați afară.
29 Wọn ó sì ti ilẹ̀ ìlà-oòrùn, àti ìwọ̀-oòrùn wá, àti láti àríwá, àti gúúsù wá, wọn ó sì jókòó ní ìjọba Ọlọ́run.
Și vor veni de la răsărit și apus și de la nord și sud și vor ședea în împărăția lui Dumnezeu.
30 Sì wò ó, àwọn ẹni ẹ̀yìn ń bẹ tí yóò di ẹni iwájú, àwọn ẹni iwájú ń bẹ tí yóò di ẹni ẹ̀yìn.”
Și, iată, sunt cei de pe urmă care vor fi cei dintâi; și sunt cei dintâi care vor fi cei de pe urmă.
31 Ní wákàtí kan náà, díẹ̀ nínú àwọn Farisi tọ̀ ọ́ wá, wọ́n sì wí fún un pé, “Jáde, kí ìwọ sì lọ kúrò níhìn-ín yìí: nítorí Herodu ń fẹ́ pa ọ́.”
În acea zi au venit unii dintre farisei, spunându-i: Ieși și pleacă de aici, pentru că Irod dorește să te ucidă.
32 Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ, kí ẹ̀yin sì sọ fún kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ náà pé, ‘Kíyèsi i, èmi ń lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde, èmi ń ṣe ìmúláradá lónìí àti lọ́la, àti ní ọjọ́ mẹ́ta èmi ó ṣe àṣepé.’
Iar el le-a spus: Mergeți și spuneți acelei vulpi: Iată, eu scot draci și fac vindecări astăzi și mâine și a treia zi voi fi făcut desăvârșit.
33 Ṣùgbọ́n èmi kò jẹ́ má rìn lónìí, àti lọ́la, àti ní ọ̀túnla: dájúdájú wòlíì kan ki yóò ṣègbé lẹ́yìn odi Jerusalẹmu.
Totuși, eu trebuie să umblu astăzi și mâine și poimâine, pentru că nu este posibil ca un profet să piară afară din Ierusalim.
34 “Jerusalẹmu, Jerusalẹmu, ìwọ tí o pa àwọn wòlíì, tí o sì sọ òkúta lu àwọn tí a rán sí ọ pa; nígbà mélòó ni èmi ń fẹ́ ràgà bo àwọn ọmọ rẹ, bí àgbébọ̀ adìyẹ ti í ràgà bo àwọn ọmọ rẹ̀ lábẹ́ apá rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fẹ́!
Ierusalime, Ierusalime, care ucizi profeții și arunci cu pietre în cei trimiși la tine; cât de des am voit să strâng pe copiii tăi, așa cum își strânge o găină puii sub aripi și ați refuzat!
35 Sá wò ó, a fi ilé yín sílẹ̀ fún yín ní ahoro. Lóòtítọ́ ni mo sì wí fún yín, ẹ̀yin kì yóò sì rí mi títí yóò fi di àkókò tí ẹ̀yin ó wí pé, ‘Olùbùkún ni ẹni tí ó ń bọ̀ wá ní orúkọ Olúwa.’”
Iată, casa vă este lăsată pustie; și într-adevăr vă spun: Nu mă veți mai vedea, până vine timpul când veți spune: Binecuvântat este cel ce vine în numele Domnului.