< Luke 13 >

1 Àwọn kan sì wá ní àkókò náà tí ó sọ ti àwọn ará Galili fún un, ẹ̀jẹ̀ ẹni tí Pilatu dàpọ̀ mọ́ ẹbọ wọn.
W tym samym czasie niektórzy z [tam] obecnych oznajmili mu o Galilejczykach, których krew Piłat zmieszał z ich ofiarami.
2 Jesu sì dáhùn ó wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ṣe bí àwọn ará Galili wọ̀nyí ṣe ẹlẹ́ṣẹ̀ ju gbogbo àwọn ará Galili lọ, nítorí wọ́n jẹ irú ìyà bá-wọ̀n-ọn-nì?
A Jezus im odpowiedział: Czy myślicie, że ci Galilejczycy byli większymi grzesznikami niż wszyscy inni Galilejczycy, że to ucierpieli?
3 Mo wí fún yín, bí kò ṣe pé ẹ̀yin pẹ̀lú ronúpìwàdà, gbogbo yín ni yóò ṣègbé bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́.
Bynajmniej, mówię wam, lecz jeśli nie będziecie pokutować, wszyscy tak samo zginiecie.
4 Tàbí àwọn méjìdínlógún, tí ilé ìṣọ́ ní Siloamu wó lù, tí ó sì pa wọ́n, ẹ̀yin ṣe bí wọ́n ṣe ẹlẹ́ṣẹ̀ ju gbogbo àwọn ènìyàn tí ń bẹ ní Jerusalẹmu lọ?
Albo czy myślicie, że tych osiemnastu, na których runęła wieża w Siloam i zabiła ich, było większymi winowajcami niż wszyscy ludzie mieszkający w Jerozolimie?
5 Mo wí fún yín, bí kò ṣe pé ẹ̀yin ronúpìwàdà, gbogbo yín ni yóò ṣègbé bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́.”
Bynajmniej, mówię wam, lecz jeśli nie będziecie pokutować, wszyscy tak samo zginiecie.
6 Ó sì pa òwe yìí fún wọn pé, “Ọkùnrin kan ní igi ọ̀pọ̀tọ́ kan tí a gbìn sí ọgbà àjàrà rẹ̀; ó sì dé, ó ń wá èso lórí rẹ̀, kò sì rí nǹkan.
I opowiedział [im] taką przypowieść: Pewien [człowiek] miał drzewo figowe zasadzone w swojej winnicy. Przyszedł i szukał na nim owocu, lecz nie znalazł.
7 Ó sì wí fún olùṣọ́gbà rẹ̀ pé, ‘Sá à wò ó, láti ọdún mẹ́ta ni èmi ti ń wá í wo èso lórí igi ọ̀pọ̀tọ́ yìí, èmi kò sì rí nǹkan: ké e lulẹ̀; èéṣe tí ó fi ń gbilẹ̀ lásán pẹ̀lú?’
Wtedy powiedział do rolnika: Oto od trzech lat przychodzę, szukając owocu na tym drzewie figowym, lecz nie znajduję. Zetnij je, bo po co ziemię [na darmo] zajmuje?
8 “Ó sì dáhùn ó wí fún un pé, ‘Olúwa, jọ̀wọ́ rẹ̀ ní ọdún yìí pẹ̀lú, títí èmi ó fi tu ilẹ̀ ìdí rẹ̀ yíká, títí èmi ó sì fi bu ìlẹ̀dú sí i.
Lecz on mu odpowiedział: Panie, zostaw je jeszcze na ten rok, aż je okopię i obłożę nawozem.
9 Bí ó bá sì so èso, o dara bẹ́ẹ̀: bí kò bá sì so, ǹjẹ́ lẹ́yìn èyí nì kí ìwọ kí ó ké e lulẹ̀.’”
Może wyda owoc, a jeśli nie, wtedy je zetniesz.
10 Ó sì ń kọ́ni nínú Sinagọgu kan ní ọjọ́ ìsinmi.
I nauczał w jednej z synagog w szabat.
11 Sì kíyèsi i, obìnrin kan wà níbẹ̀ tí ó ní ẹ̀mí àìlera, láti ọdún méjìdínlógún wá, ẹni tí ó tẹ̀ tán, tí kò le gbé ara rẹ̀ sókè bí ó ti wù kí ó ṣe.
A była [tam] kobieta, która od osiemnastu lat miała ducha niemocy i była pochylona, i w żaden sposób nie mogła się wyprostować.
12 Nígbà tí Jesu rí i, ó pè é sí ọ̀dọ̀, ó sì wí fún un pé, “Obìnrin yìí, a tú ọ sílẹ̀ lọ́wọ́ àìlera rẹ.”
Gdy Jezus ją zobaczył, przywołał ją do siebie i powiedział: Kobieto, jesteś uwolniona od swojej choroby.
13 Ó sì fi ọwọ́ rẹ̀ lé e, Lójúkan náà a sì ti sọ ọ́ di títọ́, ó sì ń yin Ọlọ́run lógo.
I położył na nią ręce, a ona natychmiast wyprostowała się i chwaliła Boga.
14 Olórí Sinagọgu sì kún fún ìrunú, nítorí tí Jesu mú ni láradá ní ọjọ́ ìsinmi, ó sì wí fún ìjọ ènìyàn pé, ọjọ́ mẹ́fà ní ń bẹ tí a fi í ṣiṣẹ́, nínú wọn ni kí ẹ̀yin kí ó wá kí á ṣe dídá ara yín, kí ó má ṣe ní ọjọ́ ìsinmi.
Wtedy przełożony synagogi, oburzony tym, że Jezus uzdrowił w szabat, powiedział do ludzi: Jest sześć dni, w których należy pracować. W te dni przychodźcie i leczcie się, a nie w dzień szabatu.
15 Nígbà náà ni Olúwa dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Ẹ̀yin àgàbàgebè, olúkúlùkù yín kì í tú màlúù tàbí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ kúrò ní ibùso, kì í sì í fà á lọ mu omi ní ọjọ́ ìsinmi.
Ale Pan mu odpowiedział: Obłudniku, czyż każdy z was w szabat nie odwiązuje swego wołu albo osła od żłobu i nie prowadzi, żeby go napoić?
16 Kò sì yẹ kí a tú obìnrin yìí tí í ṣe ọmọbìnrin Abrahamu sílẹ̀ ní ìdè yìí ní ọjọ́ ìsinmi, ẹni tí Satani ti dè, sá à wò ó láti ọdún méjìdínlógún yìí wá?”
A ta córka Abrahama, którą szatan wiązał już osiemnaście lat, czyż nie miała być uwolniona od tych więzów w dzień szabatu?
17 Nígbà tí ó sì wí nǹkan wọ̀nyí, ojú ti gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀, gbogbo ìjọ ènìyàn sì yọ̀ fún ohun ìyanu gbogbo tí ó ṣe.
A gdy to mówił, zawstydzili się wszyscy jego przeciwnicy, a cały lud cieszył się ze wszystkich chwalebnych czynów dokonywanych przez niego.
18 Ó sì wí pé, “Kín ni ìjọba Ọlọ́run jọ? Kín ni èmi ó sì fiwé?
Potem [Jezus] powiedział: Do czego podobne jest królestwo Boże i z czym je porównam?
19 Ó dàbí hóró musitadi, tí ọkùnrin kan mú, tí ó sì sọ sínú ọgbà rẹ̀; tí ó sì hù, ó sì di igi ńlá; àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run sì ń gbé orí ẹ̀ka rẹ̀.”
Podobne jest do ziarna gorczycy, które człowiek wziął i posiał w swoim ogrodzie. Wyrosło i stało się wielkim drzewem, a ptaki niebieskie gnieździły się w jego gałęziach.
20 Ó sì tún wí pé, “Kín ni èmi ìbá fi ìjọba Ọlọ́run wé?
I znowu powiedział: Do czego przyrównam królestwo Boże?
21 Ó dàbí ìwúkàrà, tí obìnrin kan mú, tí ó fi sínú òsùwọ̀n ìyẹ̀fun mẹ́ta, títí gbogbo rẹ̀ ó fi di wíwú.”
Podobne jest do zakwasu, który wziąwszy, kobieta włożyła w trzy miary mąki, aż wszystko się zakwasiło.
22 Ó sì ń la àárín ìlú àti ìletò lọ, ó ń kọ́ni, ó sì ń rìn lọ sí Jerusalẹmu.
I nauczał, chodząc po miastach i wioskach [i] podążając w kierunku Jerozolimy.
23 Ẹnìkan sì bi í pé, Olúwa, díẹ̀ ha kọ ni àwọn tí a ó gbàlà? Ó sì wí fún wọn pé,
I ktoś go zapytał: Panie, czy mało jest tych, którzy będą zbawieni? On zaś im odpowiedział:
24 “Ẹ làkàkà láti gba ojú ọ̀nà tóóró wọlé, nítorí mo wí fún yín, ènìyàn púpọ̀ ni yóò wá ọ̀nà láti wọ̀ ọ́, wọn kì yóò sì lè wọlé.
Usiłujcie wejść przez ciasną bramę, bo mówię wam, że wielu będzie chciało wejść, lecz nie będą mogli.
25 Nígbà tí baálé ilé bá dìde lẹ́ẹ̀kan fùú, tí ó bá sí ti ìlẹ̀kùn, ẹ̀yin ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í dúró lóde, tí ẹ ó máa kan ìlẹ̀kùn, wí pé, ‘Olúwa, Olúwa, ṣí i fún wa!’ “Òun ó sì dáhùn wí fún yín pé, ‘Èmi kò mọ̀ ibi tí ẹ̀yin ti wá.’ Bẹ́ẹ̀ ni èmi kò mọ̀ yín.
Gdy gospodarz wstanie i zamknie drzwi, zaczniecie stać na zewnątrz i pukać do drzwi, mówiąc: Panie, Panie, otwórz nam! A [on] wam odpowie: Nie znam was [i nie wiem], skąd jesteście.
26 “Nígbà náà ni ẹ̀yin ó bẹ̀rẹ̀ sí wí pé, ‘Àwa ti jẹ, àwa sì ti mu níwájú rẹ, ìwọ sì kọ́ni ní ìgboro ìlú wa.’
Wtedy zaczniecie mówić: Jedliśmy i piliśmy z tobą, i nauczałeś na naszych ulicach.
27 “Òun ó sì wí pé, ‘Èmi wí fún yín èmi kò mọ̀ ibi tí ẹ̀yin ti wá; ẹ lọ kúrò lọ́dọ̀ mi gbogbo ẹ̀yin tí ń ṣiṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀.’
A on powie: Mówię wam, nie znam was [i nie wiem], skąd jesteście; odstąpcie ode mnie wszyscy, którzy czynicie nieprawość.
28 “Níbẹ̀ ni ẹkún àti ìpayínkeke yóò wà, nígbà tí ẹ̀yin ó rí Abrahamu, àti Isaaki, àti Jakọbu, àti gbogbo àwọn wòlíì, ní ìjọba Ọlọ́run, tí a ó sì ti ẹ̀yin sóde.
Tam będzie płacz i zgrzytanie zębów, gdy ujrzycie Abrahama, Izaaka, Jakuba i wszystkich proroków w królestwie Bożym, a samych siebie wyrzuconych precz.
29 Wọn ó sì ti ilẹ̀ ìlà-oòrùn, àti ìwọ̀-oòrùn wá, àti láti àríwá, àti gúúsù wá, wọn ó sì jókòó ní ìjọba Ọlọ́run.
I przyjdą inni ze wschodu i z zachodu, z północy i z południa, i zasiądą za stołem w królestwie Bożym.
30 Sì wò ó, àwọn ẹni ẹ̀yìn ń bẹ tí yóò di ẹni iwájú, àwọn ẹni iwájú ń bẹ tí yóò di ẹni ẹ̀yìn.”
Tak oto są ostatni, którzy będą pierwszymi, i są pierwsi, którzy będą ostatnimi.
31 Ní wákàtí kan náà, díẹ̀ nínú àwọn Farisi tọ̀ ọ́ wá, wọ́n sì wí fún un pé, “Jáde, kí ìwọ sì lọ kúrò níhìn-ín yìí: nítorí Herodu ń fẹ́ pa ọ́.”
W tym dniu przyszli niektórzy z faryzeuszy i powiedzieli mu: Wyjdź i odejdź stąd, bo Herod chce cię zabić.
32 Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ, kí ẹ̀yin sì sọ fún kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ náà pé, ‘Kíyèsi i, èmi ń lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde, èmi ń ṣe ìmúláradá lónìí àti lọ́la, àti ní ọjọ́ mẹ́ta èmi ó ṣe àṣepé.’
I powiedział im: Idźcie i powiedzcie temu lisowi: Oto wypędzam demony i uzdrawiam dziś i jutro, a trzeciego dnia zakończę.
33 Ṣùgbọ́n èmi kò jẹ́ má rìn lónìí, àti lọ́la, àti ní ọ̀túnla: dájúdájú wòlíì kan ki yóò ṣègbé lẹ́yìn odi Jerusalẹmu.
Jednak dziś, jutro i pojutrze muszę przebyć drogę, bo niemożliwe jest, aby prorok zginął poza Jerozolimą.
34 “Jerusalẹmu, Jerusalẹmu, ìwọ tí o pa àwọn wòlíì, tí o sì sọ òkúta lu àwọn tí a rán sí ọ pa; nígbà mélòó ni èmi ń fẹ́ ràgà bo àwọn ọmọ rẹ, bí àgbébọ̀ adìyẹ ti í ràgà bo àwọn ọmọ rẹ̀ lábẹ́ apá rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fẹ́!
Jeruzalem, Jeruzalem, które zabijasz proroków i kamienujesz tych, którzy są do ciebie posłani. Ile razy chciałem zgromadzić twoje dzieci, tak jak kokoszka [gromadzi] swoje kurczęta pod skrzydła, a nie chcieliście!
35 Sá wò ó, a fi ilé yín sílẹ̀ fún yín ní ahoro. Lóòtítọ́ ni mo sì wí fún yín, ẹ̀yin kì yóò sì rí mi títí yóò fi di àkókò tí ẹ̀yin ó wí pé, ‘Olùbùkún ni ẹni tí ó ń bọ̀ wá ní orúkọ Olúwa.’”
Oto wasz dom zostanie wam pusty. Zaprawdę powiadam wam, że nie ujrzycie mnie, aż przyjdzie [czas], gdy powiecie: Błogosławiony, który przychodzi w imieniu Pana.

< Luke 13 >